Jiji Owo Gbe

From Wikipedia

Jíjí Owó Mèkúnnù Gbe Lo Si Òkè Òkun

Ní géré tí àwon ológun ti lé àwon olósèlú tí wón gba ètò ìjoba lówó àwon òyìnbo amúnisìn ni orílè èdè yìí ti wo wàhálà kí àwon olórí máa kówó je. Lópò ìgbà òkè òkun ni wón sábà n kó irú àwon owó wònyìí lo. Òkan kò sé òkan ni òrò àwon ìjoba òhún títí di àsìkò yìí. Ni báyìí gómìnà ìpínlè méjì ni wón ti fèsùn kan pé wón ba òbítíbitì owó lówó won ní ilè òkèèrè.

Gégé bí ìwé ìròyìn Daily Sun ti ojo kejì osù kejìlá odún 2005 se so, òkan nínú won tilè sa mo àwon òyìnbó lówó nípa mímúra bí obìnrin. Owó kò tilè tí ì máa té àwon asiwájú oníjégúdújerá yìí tí Orlando fi ké gbàjarè. Ní àsìkò ìjoba ológun Buhari tí Orlando gbé àwo yìí jade yen àwon díè tí wón jé agbódegbà won ni owó tè: Bí àpeere,

Lílé: Wón ti kò gbogbo kàlòkàlò

Tó ń kó wa lówó ní Nàìjíríà

Òpòlopò ń sèwòn nítorí owó Nàìjíríà o mo wí o

Ègbè: Ùbéfu ò nákó nana yeyè

Sùbùnàdò ò nákó nana yeyè

Lílé: Òpò òsìsé won ra mótò sónà repete

Opò òmòwé, wón pé ra won ni Director

Opélopé oba Èdùmàrè ló ń tójú wa ní Nàìjíríà ò

Ìyàn ìbá ti pànìyàn torí owó wa tón ko lo o baba o


Òtìto ni òrò tí Orlando so nínú àyolò oke yìí. A wòye pé ìwà jegúdú jerá yìí wà ní ààrin olósèlú àwùjo Hausa. Àkíyèsí wa ní pé ó sòro fún àwon òdómodé àwùjo Hausa láti wo ojú àgbàlagbà. Bóyá èyí ni ó fa sábàbí dídáké tí òpòlopò okorin ilè Hausa dáké títí kan Dan Maraya.

Ní àwùjo Yorùbá ìgbàgbó wa ni pé, oba kì í pa òkorin, bí ó tilè jé pé a rí àwon àpeere díè níbi tí òkorin ti dáràn lówó àwon olórí (Adédèjì 1981:231). Èyí kò fi gbogbo ara rí béè ní àwùjo Hausa, Ó sì se àkóbá díè fún òrò ìsèlú won nítorí kò sí ìkóra-eni-ní-ìjánu.