Oju ti Ifa fi n Wo Obinrin
From Wikipedia
OJÚ TÍ IFA FÍ WO OBINRIN
Ifá je òrìsà kan pàtàkì láàárín àwon Yorùbá àwon Yorúbà gbàgbó wípé Olodumare lo ran ifá wa láti Ode Orun láti wa fi Ogbón rè tún ilé ayé se. Ogbón ìmò àti Òye tí Olódùmarè fi fún ifá ló fun ifá ní ipò ńlá láàárín àwon ìbo ile Yorùbá ….”a kéré-finú-sogbón”ni oríki ifá. Eleyi lo fi han wa gégé bí Abimbola (1969) ti gbe kala.
Nínú isé àgbékalè Ilesanmi ó wa je ki a mo wípé ifá ni alárínà fún gbogbo omo Oodua oun ni ó dabi agbenuso fún gbogbo àwon òrìsà àti Olódùmarè ohùn sì la kà sí eni to ń se àjèwò fún gbogbo mùtúmùwà. Èyí wa fún ni ibò asojú fún gbogbo àwon Irúnmolè yòókù. Aroko leti opon ifa 1998.
Ifa je ewi tí ó máà ń lo láti ilú kan sì èkejì láti dífá. Èyí lo se okùnfa bíbá òpò obìnrin pàdé ó sI fun ni ànfáàní láti fe ìyàwó púpò torí irúfé isé ti ifá ń se. Èyí sí lo fa to fi sese fún ifá láti mo ìwà won ó wú oniruuru ìwà yìí jáde torí àjosepò rè pèlú àwon Obìnrin. Ó maa ń sawo kiri ní. Gbogbo ibi tí ifá ba ti dé lo ti ń yan ìyàwó, èyí lo mu ifá rí àrísá àwon Obìnrín.
Obìnrín ní a le pè ni ìdàkejì Okùnrin tí a ba wo Tíórì Àbùdá onibeji fún àgbéyèwò lítírésò ifá tí Ilésamí pàjúbà re Tíórì yìí nì ó je kí á mo pé laisi òtún osi ko le dádúró.
Erongba opileko yìí ni láti tàn ìmólè sí ipò tí ifá fi àwon Obìnrin si Àkíyèsí àwon ipò wònyí si han nínú àwon ese ifá. Ojú méjì Òtòòtò ni ifá fi wo àwon Obìnrin
(i) Ó rí won gégé bi eni réré ti ko se maniyen to léwà.
(ii) Ifá rì àwon obìnrin ní ìdàkejì gégé bi èsù tàbí olubi èdá.
Sebí tibi tire la dálé ayé. Béè sI ni a kìí dára ka ma kù síbì kan. Àwon òbinrin la ba máà pè ní ejò gégé bí àgbékalè ifá. Nítorí ìdí èyí ifá ro àwon okùnrin láti gbón nínú gbón lode tí òrò ba ti di òrò obìnrin.
OBÌNRIN GÉGÉ BÌÍ KÒSÉÉMÀNÍ TÀBÍ ENI RERE
Nínú ìpín yìí ifá bèrè sí ni se àfihàn wón láti òde pé wón tewà ó si rí obìnrin gégé bi eni rere. Ewà won sI maa ń jeyo nínú àwò tí Olódùmarè fit a won lóre àto omu ti ó fi se àfikún ewà won. Omú tàbí oyàn obìnrin ní iyì rè ohun si ni onfa to ń fa àwon okùnrin to si ààbí èmú to ń mu won mólè lára obìnrin òdí méjì, ìjìnlè ohun Eleu ifá Apa kinni pg 54-1-3 fìdí èyí mílè pé
Funfun niyì eyin
Egun gadaaga niyi orun
Omu sìkì siki niyi obinrin
Omu sikisiki niyi obinrin pg 54 1-4
Ohun iyi àti àmúyera ní fún oko re bi èyin odi meji Obinrin ba funfun. Bakannaa ni ifá tún fi ye wa pe ki obinrin lómú ko lopin ewa. Sùgbón ìmótótó náà tún se pàtàkì láti le e perí okùnrin wale ìjìnlè ohùn enu ifá láti owo Wade Abimbola Apa kini pg 51-25-26.
Síyínka Súnyinka
Baláfúnjú ba ji a sìnyìnká sóko pg. 51 25-26.
A ko gbódò gbàgbé wipe ara ewà ita ti òrúnmìlà ri lára Àwòrán ní ó fig be e ni ìyàwó. Sùgbón ó jé ohun ìyàlénu pe bi àwòrán tí joju to ko ìwà àrokò ti ifa ń fi èyí pa ní pe ewà kii se ogbo nìkan. Bi a ti ń wo ewà ifa ni ó ye ki a naa wo ti inú.
Ifá wo ewà inú àwon obìnrin ni orísìírìsí ònà Aabo je ìrànlówó fún òrúnmìlà nigba to lalèjo meta Iku, Àrùn àti Èsù. Ààbò lo ko nnkan ìlò oko re lo ta ni ojà Ejigbomekan ní owó póókú ó ra ounje won si tójú àwon àlejò won. Ìwa ti Ààbò wù yìí mu kí àwon àlejò méétèta wònyí fì ifá sílè laipa. Won fún Òrúnmìlà ní èbùn ki won ó to fí ilé rè sílè. Inú Òrúnmìlà dun nítorí ìwà Ààbò àti ori re tí ó ko ran-an. Èyí si mu kì Òrùnmìlà feran Ààbò.
Òdá Owo awo kóro
Ààbò Obìnrin rè - pg 20 1-2
Ifá ó sI ní Ookan a a yo na
Ní Òrúnmìlà ba pé Ààbò obìnrin rè pé kí ó kó àwon nnkan ìní òun lo sójà lo tà. Ìjìnlè ohun Enu ifa iwe kinni
Ifa fe ìwà náà gégé bí aya Òle àti òbùn ayé ní ìwà je. Èyí mí ki òrúnmìlà le e lo ki lo si nnkan ò ba gún régé mó àwon ènìyàn sá lódò re. Àpónlé kò si fún òrúnmìlà mo bìí ti télè sebi ko kuku sí àpónlé fún oba tí kò ní olorì.
Ká mú rágbá
Ká fi ta rágbá
Ka mu ràgbà
Ka fit a ràgbà
Iwa la n wa o, ìwà
Alara ó ri ìwà fun mi
Ìwà la ń wa o ìwà…
Ìwà ni o je gégé bí orison áàsikí fún Òrùnmìlà sùgbón ko mo iyì ìwà àfi ìgbà tí ìwà fi ilé Òrúnmìlà sílè. Èmí náà je okan lára obìnrin òrúnmìlà. Ifá fi èmí hàn gégé bi òpómúléró. Ìdí nìyí tí Òrúnmìlà fí gbé èmí ni ìyàwó ko ba le se rere láyé. Á gbódò mò wípé emi ní ó gbé ìwá ró. LaisI èmí ko si àrà tí ènìyàn le da láyé. Aadogun, aadogbon, owó èmí ni gbogbo re wa. Àwon Yorùbá sì gbàgbó wípé èmí gígún ni san ìyà Òrúnmìlà ko le gbàgbé emí nítorí ohun rere ti èmí fún Òrúnmìlà ní ànfààní láti se. Ire gbogbo tí èdá ń wa kiri owó èmí ní gbogbo re wa. Fun àpeere:-
A dia fun Òrúnmìlà
Níjó to ń lo r’emi omo Olódùmarè s’Obinrin
Ó ní àsé bemi ò ba bó
Owo ń be
Hin hin owo ni be
Àsà bemi o ba bo
Aya ń be
Hin hin aya ń be
Àsé bemi ò bá bó
Omo n be
Hin hin omo ń be
Ase bemi ò bá bò
Ire gbogbo ń be
Hin hin ire gbogbo n be …
Wande Abimbola Ìjìnlè ohùn enu ifá Pg 16 (Eji ogbè). Apa kinni
Odù náà je oken nínú àwon ìyàwó òrúnmìlà tí o ko orire ràn án. Alátìleyìn ni odù je fún Òrúnmìlà. O dìgbà tomo èkósé ifa ba to fojú ba odù ko to deni ara re. Èyí túmò si pé babaláwo tí kò ba fojú bodù kò tii dangajia.
Eni bá fojú bodù
Yoo si dawo
A fojú bodù a rire
OBÌNRIN GÉGÉ BI OLUBI
Àbùdá kejì yìí ní yóò tu tìfun tèdò ihà kejì tí ifá ko si àwon obinrin. Ifá ri àwon Obinrin gégé bi eni ibi, alásejù, òjòwú àti àjé. Ó fi ìhà yìí hàn tori pe a kìí dara ka ma kù sibi kan.
Ifá fi won wé aláigboràn ewúré tí wón máà ń se àtojúbò àwon ohùn tí ko kàn wón. Bi àpeere Yemòó fe mo ìdí agbára Óòsáála oko rè pèlú èdó tí ó fi ń pa eran ohun tójú tíle-túle alaigboran ń ri ní ojú re rí lojo yìí. Òrúnmìlà so fún àwon ìyàwó yòókù láti mase yojú wo òròmòdìmòdì obìnrin rè tuntun.
Ìyáálé pé àwon yòókù láti lo yojú wo ìyàwó tuntun yìí inú bí ìyàwó tuntu, o si jade. Ó sì fi won ré bayí ni Àjàkálè àrùn si wole to won. A ko le fí gbogbo ara da ìyaálé àti àwon ìyàwó yòókù lébi torí Òrúnmìlà ti ye kì ó fi ìyàwó tuntun han àwon to ba ní ilé sùgbón ó kò ko se èyí nípa ojú tí òrúnmìlà fí wo Obìnrin tí a le so pe Òrúnmìlà lo fí owó ara re da ilé ara rè ru. Eni ba wa wàhálà dandan ni ki ori i.
Ifá tun fí àwon obinrin hàn gégé bí òjòwú, ti won kìí fe ki oko won fe ìyàwó mìíràn le won àfi àwon nìkan. Fún àpeere:
Òkan soso péré lobìnrin
Dùn mo lówó oko
Bí won ba di méjì won a dòjòwú
Bí won ba di meta
Won a deta ń túlé
Bí won bad è merin
Won a dí iwò lo rín mi ni mo rin o
Bi won ba dí marun
Won a di lágbájá ni ó run oko
Wa tan lóhùn susuusu
Bì wón ba dí méfà
Won a dìkà
Bi wón ba de meje
Won a d’àjé
Bí wón ba di mejo
Wón a di ìyá alátàrí bàmbà…
Ìjìnlè Ohùn Enu Ifá Apá Kìínní pg 29-43 (Òyèkú meji) Wande Abimbola
Ohun tí o je ìjojú ní wípé Ifá gan-an mo pé ó sàn fún okùnrin láti fe ìyàwó kan. Èsè amomoda ni èyí ko ye ki Ifá maa fe ìyàwó lórí ara won.
Eke àti Òdàlè ni Ifá tún pe àwon obìnrin. Ohùn tí Ifa ń so níbí ni pe Obìnrin ko se fi inú hàn sùgbón ibeere tí a ba bi Ifá ni pe se okúnrin ni o se fi inú hàn. Bi o ti wa ni lìkì ni ó wa ni gbanja
Obinrin leke
Obinrin lodale
Keniyan se pele
Ki o ma finu han f’oobinrin (CL Adeoye pg 243 ese ifá kan nínú Obara meji)
Ifá te síwájú nìpa pipe àwon obìnrin ni dókodóko àti alágbèrè. Èro ifá ni pé àlè yiyan yìí kii je ki won tonu lopo igba pe eni to ba keré soko ni won maa ń ba dálè.
Àgbìgbòniwònràn, The unfaithful Ifá priest
You have been seeing bad things,
Worse things are yet to come;
Worse things the father of bad things
Ifa divination was performed for Agbigboniworan
Who was going to the house of Onkoromebi to perform divination
Onikoromebi, husband of an adulterous wife
It was because of the incessant adultery
Of his wife that oniworonebi
Performed divination
Igba ti o fìyà je obinrin naa tan
O gbe ju, agbala
O si de e lokun mólè
Ni àgbàlá ni onikoromebi fi ìyàwó re sI
Ti o fì lo bìfa léèrè
Àgbìgbò ní ki Onikoromebi o se sùúrù
O ní eni tí o torii re bi ifa léèré
Mbe loride nínú àgbàlá
Igba ti onikoromebi gbo
Oju ti i
Ko lee lo tu ìyàwó rè sílè mo
Ó ní ki Àgbìgbò o lo ba òun tu u sílè
Ìgbà tí Agbìgbo débè
Dípò ki o tu obìnrin náà sílè
fefe ni ń fe e….
(Ifa Divination Poetry pg 87-88)
Nígba tí ìyàwó onikoromebi náà yan babalawo ti won ni ko ba won wo aisan agbere lara re. Sùgbón ojo yìí ní ibi won wole nítorí bibe ní oníkòròmebi be àwon mejeeji. Babalawo tì won ni ko wo aya onikoromebi ko ni ètó lati se èyí. Bí wón ba pe obìnrin ni dokodoko. Obìnrin ko le da oko dó laì ri okunrin. Fi obìnrin é yálè yàlè alainisuru a ri eleyi nínú Sixteen great poems of Ifa Not long again. They sent for Òrúnmìlà in the abode of Olokun when Òrúnmìlà was going he did not take Òrò his wife along he promised to return on the seventeenth day. He gave sixteen òké measures of cowries to òrò. He also gave her clothes and plenty of food in the third month that Òrúmìlà had stayed away. For Example:
Òrò met Ońdàáró
They agreed to be Concubines
Ondaaro gave her five oke measures
Of cowries He cohabited with her,
And he became pregnant.
Òrò met onigoosun
After they had talked together
Onìgoosun gave her ten Oke measures
Of cowries
And cohabited with her
And again she became pregnant
Not long again òrò met a man named Olúùkóoló He gave har tiventy oke measures of cowries after they hed fun with each other òrò became pregnant again. All together the children of Òrò thus became six and they were all boys out of the six children three were children of Concubines.
Nínú esè Ifá yìí fi hàn wá wípé Owo l’obinrin mò gbogbo àwon meteeta to ba dálè yìí owó ní won fi hàn òrò.
Aritenimoo wi, a fi apadi fenfe bo tirè mólè ni Ifá ibeere ti a ba bi òrúnmìlà nip e se ko ba obinrin kankan ni àjosepò ni ìrìn àjò re. Ko si eni to mo iye omo ti o`hun na bi si àjò. The Sixteen Great Poems of Ifa pg 216-221 Wande Abimbola
Ifá rí obinrin han gégé bi àjé
Fun àpeere:
Béè ba gbolagbalagba epo òun ewùso
E lo lee ko fún ìyàmi Òsòròngà
Apa nimawaagun, Olokiki Orù
Ajedo-tútù-mo-bi
Obinrin kukuru regiregi
(The 16 Great Poems of Ifa pg 242 Wande Abimbola)
Àwon obìnrin náà ni Ifá tún fihàn bí aforesunu se. Won fore su Òrúnmìlà nílé ayé pé àwon o ni sòkalè ní ikùn re mó àfìgbà to ba rúbo.
Won ní kí ní ń je siso kale
Won ni a tun sòkalè mó
Òrúnmìlà ti mo Oko ni oko ikun to gbin èpà síbè. O mo pé ìhòhò ní àwon eleye wa ko to gbà láti se won ní àánú. Kìí se Òrúnmìlà nikan ní àwon eleye be. Òrúnmìlà tí gbàgbé pe bí ojo oore ba pé asiwèrè a gbàgbé àti pé ìwòn ní oore.
Aláwomó àti alakooba ní won gégé bi ìwà ti ìyá arúgbó tí a fi se àpeere nínú òyèkú méjì wù. Nígbà to fòrò isú lo enikan ti ko gba a je o fi owo epo sàmì sìi lára. Ebi kii se ebi eni to fi owó epo to o ni leke eni to rin ìrìn ìwàsà o di dandan kan fi èkùró lo o Fun àpeere:
Ó mú owo epo
Ó fi to mi léèkée mi òtún itororo itororo
Ó mú owo epo
Ó fi to mi leeke mi òsì itòròrò itòròrò
Ìjìnlè ohùn enú ifá pg 29-107-110 Òyèkú meji Wande Abimbola
Ifá tún je ka mo pé ìkà àti òfinràn ni won. Nínú méjì Yemoo ìyàwó orisà ńlá lo ji omi àwon eleye pon to so tun fo aso òdé re sínú odò náà
The witches asked, Did
She stab herself and Èlúlù
Replied she did not
Stab herself, the blood was
From her private part (The 16 Great poem ifá)
The witches therefore swallowed both the husband and the wife. Álásejù baba àseté tún ní ifá fe won ohun ti won se náà nìyí tí ó je ki nnkan bótí mo won lówó. Won kí àsejù bo òrò won. Fun àpeere :
Igbó etílé t’oun tegbin
Adapo owó toun tiyà
Iwo o ju mi
Emi o ju o
Lara ile eni fi ń fojú di ni (Oladipo Yemitan ati Olajide Ogundele Oju Osupa Apa keta)
Ifá je ka mo wípé Olódùmarè yan òrìsà merindinlogun ó fi òbìnrin kan si wípé ki wón maa lo silé aye láti maa lo rúbo fún àwon èmí airí. Nígbà tí won dé ilé ayé osun tí ó je obìnrin àárín won ní ó maa ń se ìpèsè fún àwon èmí airi yìí.
Ní gbobgo ìgbà tí won bat i n lo gbe ebo yìí lo fún àwon emí airi yìí osun kìí tèlé won, ti won ba ti de ibè gbogbo àwon òrìsà wònyí lo maa ń ko gbogbo ìpèsè yìí je, sùgbón won ko mo wípé Olódùmarè tí fun osun ni agbára láàrín won nígbà to yá gbogbo nnken kò gún régé mó won sa ògùn títí kò je mo. Bayi ní won se pínú láàrín ara wón láti rán òrìsà ńlá lo sodo Olódùmarè sùgbón òrìsà ńlá ko láti lo. Ní ifá bá ní kí wón ran ohùn lo sódò Olódùmarè nígbà tí Ifá de ibè lo ba so fún Olódùmarè wípé nnkan ko gún régé mò o. Olódùmarè ba ni osun ń ko o ni gbogbo nnkan te ba ti n se e fi t’obinrin si.
Bayí ní gbogbo àwon òrìsà yòókù bu lo si òdò osun láti béè sùgbón òsun ko gba èbè béè lo bèrè si ni mu gbogbo won bu leyo kookan láti orí Oosala, Òrúnmìlà Sungo, oya obalùfòn àti bebe lo ó ní nnkan tí won jo ràn àwon ń ko? lo ba so fún won wípé omo to wà ní ikùn ohùn tí ohun ba fi bí obinrin Olódùmarè yóò fí àwon elomíran dipo won. Sùgbón to ba je pe okunrin ní ohun fi bi o ni ohun yoo fi won silé wípé ohùn náà ti ni lara won niyèn ni osun ba fi oyin re bi okunrin láti ìgbà yìí tí won bat í ń lò sI igbó emí airi láti lo run won maa ń lo gbé omo òsun láti fi owó tirè náà sI gbogbo nnkan ti won ba ń se tan ba se tan won à dá pada fún ìyá rè.
Igba yìí lo ti so pé tó ba je okunrin ko ma je Akin osó. Ni ki a
Ka kúnlè
Kí Obìnrin
Òbìnrin lo bi wa
Ka to di ènìyàn …
Ifá je ka mò wípé alagbará ni àwon obìnrin Olodumare lo pin won ile agbara yìí. Gbogbo bi àwon òrìsà yòókù se ń ko ípèsè yìí je òsun mo si sùgbón ó se bi ènipe ohun ko mo nnkan to ń selè.
Alagbara ní won bí won se le lo agbara won lati fi se daradara ni won fi le se búburú. (Olóyè Babalola Fatoogun (Ifá Priest) Ilobu Osogbo.)
Ifá tún so ìtàn nipa àwon obìnrin ajo àti ìpàdé to maa ń se o fi hàn bo fe lo agbara àwíse lati fig be òrò kalè ni gbogbo ìgbà tí won ba ti fe se ìpàdé.
Ni òpòlopò ìgbà gbogbo agbara àwíse to ba so labe ge. Nitorí ó dúró gégé bi agbára ìtúsílè àti agbara Hayese.
Bo se dí ojo kan àwon òfá wa ònà láti ji agbara náà gbe won ko ri bi won se lo ba ìyàwó òrúnmìlà pìyí pe to ba juwe ibi ti agbara òhún wa fun àwon àwon o fun lówó.
Ìyàwó Òrúnmìlà gba owo, o si gbe agbára náà o lo bo mo inú eérú ojú àrò. Nígba tí Òrúnmìlà fe se ìpàdé a koko gbìyànjú làtí bi ifá léèrè lori bi ìpàdé yoo se ri ni won ban i ko lo bo sango ojú eérú tori ke nnkan ba le senu ire àti pe kí àsírí to farasin le ba hàn sáyé.
Ìgbà tí Òrúnmìlà ti gbe eéru ojú aaro lati bo Sango tan lo ba ri agbara rè tí òtá to ń pè ni ìyàwó bo mo inú eeru náà. Ìgbà tí òtá ri pé won ko ri Òrúnmìlà mú náà bá tún lo ba ìyàwó re láti tún ta ete mìíràn ìyàwó Òrúnmìlà pèlú àwon òtá náà ba gbìmò láti lo ju agbara re sínú odò.
Ìgbà ti ojó àjò ń pe bò Òrúnmìlà lo bi Ifa léèrè bí ojó àjo yoo se rí nítorí ó tí mo bi obinrin se jé. Sùgbón ebo to jade sí nip é ki o lo ni eja abori ńlá kan, obi àbàtà, àti iyàn ìlèkè ko fi bo eleda re. Lílà tí Òrúnmìlà la inú eja lo ba agbára rè nínú eja. Ó gbà pe obinrin ni òdàlè ni won. (Lati enu Dro Agbájé ti won gba lenu Babalawo)
Ìtàn kan ti Ifa so fì Obìnrin hàn gégé bi òdèlè, afenimadenu olubi ènìyàn. Ifá so ìtàn nípa Òrúnmìlà ENI TÍ MO FÒRÒ WÁ LÉNU WÒ.
Oloye Babalola Falogun Ifa Priest Ilobu Osogbo.