Orlando Owoh ati Dan Maraya Jos
From Wikipedia
Orlando Owoh ati Dan Maraya Jos
ÀFIWÉ ÀKÓÓNÚ AJEMÓ-ÈKÓ-ÌWÀ-OMOLÚWÀBÍ NÍ ÀWÙJO YORÙBÁ ATI HAUSA BÍ Ó SE HÀN NÍNÚ ORIN ORLANDO OWOH ATI DAN MARAYA JOS (A COMPARATIVE STUDY OF THE ETHICAL VALUES OF THE YORÙBÁ AND HAUSA AS REFLECTED IN THE SONGS OF ORLANDO OWOH AND DAN MARAYA JOS).
SUNDAY LAWRENCE ADÉSÒKÀN
ÀSAMÒ
Isé yìí se àgbéyèwò kókó inú orin Orlando Owoh àti Dan Maraya Jos. A wo àfojúsùn àwon òkorin méjéèjì a sì fi wón wé ara won. Ní àfikún, isé yìí wo ipa ti àwùjo kòòkan tí àwon orin òhún je mo ni lórí re bí ó se je mó ìsèdá, òkìkí àti ìtéwógbà àwon orin òhùn. Nínú àwon kókó tí ó jeyo nínú àwon orin òkorin méjéèjì, a yan èkó ìwá omolúwàbí ni ààyò nítorí pé a gbà pé àìní èkó ìwà omolúwàbí jé pàtàkì nínú ìsòro tí ó dojú ko àwùjo Yorùbá àti Hausa.
Lára àwon ogbón ìsèwádìí tí a lò ni síse àkójopò, àdàko àti ìtumò àwon orin òhún. A se àsàyàn ènìyàn méwàá láti inú ìpínlè merin tí ó je ti Yorùbá a sì se ìwádìí lénu won nípa orin Orlando Owoh. Bákan náà ni a lo ìlànà yìí fún ènìyàn méwàá tí a yàn láti inú ìpínlè merin tí a fi òrò wá lénu wò lórí orin Dan Maraya. Gbogbo àwon èrí tí a kó jo ni a fi ìlànà tíórì ìmò-ìfojú-ìbára-eni-gbé-pò wo lítírésò tú palè.
A rí àrídájú pé àyípadà pàtàkì ti dé bá okòwò orin kíko ní àwùjo méjéèjì. Ki ìmò èro tí ó jé kí ó seése fún wa láti gba orin sílè sórí káséètì to dé, léyìn tí a bá gbó orin tan ni à ń náwó fún òkorin. Ní òde òní a ó ti sanwó káséètì tí ó ní orin nínú kí ó tó wa di pé à ń gbó o.
Isé ìwádìí yìí fi ìdí re múlè pé àyípada tí ó dé bá isé orin kíko ní àwùjo méjéèjì, túbò mú isé àwon òkorin méjéèjì rorùn gégé bí lámèétó ìwà ìbàjé híhù. Ipò won yìí ba isé àwon òkorin ìgbà ìwásè mu kí ó tó di pé àsà àwon aláwò funfun so ó di ìdàkudà. Name of Supervisor: Dr. J.B. Agbájé No. of Pages: 267
ABSTRACT
This study examined the contents of the songs of Orlando Owoh and Dan Maraya Jos – with a view to contrasting them. It also analysed the motifs of the songs. In addition, it explored their socio – cultural environments which gave their compositions, the fame and acceptance they enjoyed. Out of the themes inherent , ethical values were picked out for special treatment because we believe that lack of ethics is one of the problems facing the Yorùbá and Hausa societies. The methodology involved the collection, transcription and translation of these songs. Ten randomly selected fans from four Yoruba speaking states were interviewed on Orlando’s song, while the same mode of selection was used to select people for interview on Dan Maraya’s song. The data collected were analysed within the sociological theory of literature.
It was found out that fundamental changes had taken place in the music industry in the two societies. Prior to the advent of technology, which ensured recording of music, in the traditional period, listener would always listen to music first, before appreciating the music. Nowadays, the reverse is the case. You pay for a cassette before ever having the opportunity of listening to them.
The study concluded that with the new trend in the music of the two artistes – composers, musicians are now assuming better roles as social critics. This trend conforms with their traditional roles which have been eroded and adulterated in the neo-colonial period. Name of Supervisor: Dr. J.B. Agbájé No. of Pages: 267