Alaye Die Nipa Ifa

From Wikipedia

ADELE OLUFUNKE ANN

ÀLÀYÉ DÍÈ NÍPA IFÁ

Ifa

Ifá jé òrìsà kan pàtàkì láàrin àwon Yorùbá. Àwon Yorùbá gbàgbó wí pé Olódùmarè ló rán ifá wá láti òde òrun latí wá fi ogbón rè tún ilé ayé se. Ogbón, ìmò, àti òye tí olódùmarè fi fún ifá ló fún ifá ní ipò ńlá láàrin àwon ìbo ní ilée Yorùbá. “A-kéré-finú-sogbón” ni oríkì ifá.

Ìgbàgbó Yorùbá ni wípé ní ìgbà kan rí, ifá gbé òde-ayé fún ìgbà pípé kí o tóó padà lo sí òrùn. Ní ìgbà tí ifá fi wà ní ilé ayé, ó gbé ilé-ifè fun ìgbà péréte. Sùgbón ní ìgbà tí òrùnmìlà fi wà láyé yìí naa, a tún maa lo sí òde òrun léèkòòkan tí olódùmarè bá pèé láti wá fi ogbón rè bá òun tún òde-òrùn se. Nítorí náà gbáyégbórun ni ifá ńse.

Ìtàn so fún wa wipe omo méjo ni òrúnmìlà bí nígbà tí ó wà láyé, nígbà tí ó di ojo kan ti òrùnmìlà ńse odún ni òkan nínú àwon omo yìí tíí se àbíkèhìn pátápátá báse àfójúdi sí òrúnmìlà, ni òrùnmìlà bá binú fi ayé sílè lo sí òde orun. Ni ìfá bá relé olókun kòdé mó. Ó léni té bá ri i, e sá maa pè ní baba”. Sùgbón òrùnmìlà fún àwon òmo rè méjèèjo náà ní ikin mérìndínlógùn ó ní be e délé bee bá fówóó ní, eni tè é maa bi ninu.

Ìkín mérìndinógun náà ni à ń lò lòníí láti bèèrè nnkan lówó ifá.

DÍÈ LARA ÀWON OHUN ÈLÒ IFÁ DÍDÁ

Orísìírísìí ni àwon ohun èlò tí àwon babaláwo fi í da ifá ikin ifá ni àdáyéná nínú wón. Ikin ifá jé mérìndínlógún. Ohun èlò ifá-dídá míìran ni òpèlè, èyí ló wópò jù fún ifá dídá ní ayé òde òní. Àwon babalàwo máa ńsábàá lo ikin ifá (èkùró ifá) nígbà tí wón bá mbo ifá ní oòdèè won, wón a sì lo òpèlè fun ará òdé tí ó wáá da ifá lódòo won láti ibi èso igi òpèlè ni a ti ń mú òpèlè ifá.

Ohun èlò ifá dídà míìran ní ìróké tàbí ìrófá èyí jé óá gbóńgbó kan báyìí tí a ńmú lu opón ifá bí a bat í ńki ifà lo àwon olóyè ifá a máa fi ehín erin gbé ìrókée ti won.

Ohun èlò ifá dídá míìran opón ifá, nínú opón ifá ni a ní lati kó gbogbo ohun èlò ifá dídá tí a ti ká sílè wonyìí sí bá a bá ti ńdá ifá. Orísi opón ifá ló wà opón kékeré wà, opón ńlá sì wà pèlú.

Àwon babaláwo a máa ní owó eyo àti égúngún nínú ohun èlò ifá dídá won, owó eyo dúró fún béèni, egungún sì dúró fún béè ko nígbà tí a bá di ìbò béèrè nnkan lówó ifá-owó-eyo àti égúngún yìí tí a dì mówó ni à ń pè ni ìbò.

Gbogbo ohun èlò ifa dídá tí mo kà sílè yìí ni a ńkó sínú àpò kan tí àwon babaláwo ńgbé kó èjìká báyìí tí à ń pè ni àpòo jèrùgbá, enikéni tí o bá nko àpò yìí ni à ń pè ní akápò ifá tàbí babaláwò.

EBO IFÁ

Ebo rírú se pàtàkì fún eni tí a bá dá ifá fún. bí ifá tí a dá fún ènìyàn bá se rere tàbí búbúru, oní tòhùn ni lati rúbo kí ohun tí ó dá ifá sí náà ó lè baà dará: lónà kìní:- Ebo ifá jé ounje fún òrìsà tí ifá bá so wí pé kí á rúbo, Fun àpeere, tí ènìyàn bá fé se nnkan. ti o ba bèrè lówó ifá, wón le so pé ki o lo rubo fun ògun, Ebo ifá jé ètùtù pàtàkì nítorí tí Babaláwo bání kí ènìyàn se nnkan óní láti se é, ki òun pàápàá ólè ba à ni ìgboyà wípé àteégún-àteésà, nítori èyí ní àwon babaláwo fi máa ńwí fún ení tí a ní kí ó rúbo pé kí ó wá oúnje fún àwon aládùgbóó re.

ÈSÙ ATI IFÁ

Bí a ba wo ilé àwon babaláwo, a ó ri i wí pé ère Èsú kìí wón nibè. Yangí ńlá kan o máa wà ní èbá ilé àwon babalawo. Yangí yìí dúró fún àmì Èsù. Ìgbà gbogbo ni àwon babaláwo máa gbé eboo lo si ibé, nwon a máa bu epo lé yangí náà lórí, a máa rin sún nígbà gbogbo.

Òpòlopò ni ese ifá tí o je mo Èsù. Nígbà míìran, Èsú jé ìrán ńsé fún ifá. Nígbà miran èwè, Èsú sí dá bí eni tí ńfún ifá ni agbára. Nínú ese ifá a lè rí ohun tí o jo bayin “…ni òrúnmìlà ba ti àse Èsù bonu”. ìtumò èyí ni wí pé bí ifá bá féé se nnkan lile ti ó rí bí idan, àse Èsù ló ní láti lò. Nígbà mìíràn, Èsù jé olùrànlówó fún ifá. Nígbà mìíràn, Èsù sì jé olùdánwò fún ifá.

Oríkì Èsù tí ó wà nísàlè yí ti fi hàn wà gba-n-gba pé Èsù kì ba enìkan sòré

Oríkì Èsù nìyí: “Òkú yan omo tié lódì átóńtórí omo olomo”.

IPÒ IFÁ LAARIN ÒÒSÀ YÓKÙ

Ifá jé agbòràndun fún gbogbo àwon òrìsà yókù. Bí eégún ilée baba eni ba féé bínú sí ni, láti odo ifá ni a ó ti gbò èyí wáá fún ifá ni ipo asojú fún gbogbo àwon irúnmolè yókù. Bí kò bá sí ifá, iyì àti olá ti àwon Yorùbá mbú fun gbogbo àwon òrìsà ilèe Yorùbá ró, tí ó sì nwà ońje sí won lénu.

Gégé bí a ti so síwájú, àwon omo òrúnmìlà ni òrúnmìlà fún ní ikin ifá mérìndínlógún nígbà tí ó padà lo si òrun tí ló sí wa sílé ayé mó.

Nígbà tí a bá ń sòrò ìkín, a kò ni se aláìménuba àwon ojú odù mereerindínlógún nítori ìkín mérìndínlógún náà ni à ń lò lónìí láti bèèrè nnkan lowo ifá. Àwon ojú odù mérìndínlógún àti bí wón se to tèle ara won:

(1) Èjì Ògbè

Eji ògbè Esè kínní

“Gbogbo orí àfín ewú

Abuké ló rerú òòsà mósò

Lààlààgbàjà ló ti isé è de

Adíá fún òrúnmìlà

Níjó ti ńlo rèmí omo olódùmarè sóbìnrin Esè kejì.

Eri ńlá níí sunkún ibú

Agbara giri nii sunkun ògbun

Adíá fun Aadelówo nífè

Nwón ní ó ká a kío móle

(2) Oyeku méjì, (7) Obara méjì, (12)

Òtúá méjì

(3) Ìwòrí méjì, (8) Òkànrùn méjì, (13) Òsá méjì,

(4) Òdí méjì, (9) Ògúndá méjì, (14) Ìretè méjì

(5) Ìrosùn méjì, (10) Ìká méjì,

(15) Òsé méjì,

(6) Owónrin méjì, (11) Ótúúrúopon méjì, (16) Ofún méjì,

ÀWON OMO ODÙ 

Léyìn àwon ojú odù méríndinlógún yìí, àwon òjìlérúgba odù míràn tún wà tí à ń pè ni omo odù tàbí àmúlù odù wón jé omo odù nitorí pé a gbà pé won se omodé si àwon ojú odù, à ń pè wón ni Àmúlù odù nítorí pé orúko odù méjì ni òkòòkan wón jé. F.A., èkíni nínú àwon odù wònyìí a máa je ogbeyèkú.

Àwon Yoruba ka àwon odu wònyú si òòsà pàtàkì jùlo, àwon ojù odú. F.A. Ese-ifa òwònrín méjì

(a) Ikin níi fagbáríí selé

Àtàrí ni o jóòrún ó pagbin ìsàlè

Olobonhunbonhun ni fapa ara re dá gbèdú.