Ibowo fun Agba
From Wikipedia
Ìbòwò Fún Òbí àti Àgbà
Òbí omo ni olókò tí ó wa omo wá sí ilé ayé. Ojú bàbá àti ìyá a máa rí nnkan lórí omo. Se ìdààmú oyún rírù kiri ni a lè bá abiyamo sírò ni tàbí ìsárékiri baba lori àgbo kíka àti wíwá jíje mímu? Yorùbá bò wón ní: ìyá ni wúrà, baba ni díńgí. Omo tí ó bá gbó ti àwon òbí tí ó sì bòwò fún won yóò gba ìre lénu òbí, yóò sì pé lórí ilè. Yorùbá gbà pé ó di dandan kí omodé tí ó bá warùn kì sí òbí parun.
Ní ìdá kejì èwè, tí a bá ń sòrò ìbòwò fún òbí ní àwùjo Yorùbá, kì í se bàbá àti ìyá eni nìkan ni a ní lókàn. Gbogbo eni tí ó bá ju ni lo ni. Ìjìyà ìparun kan yìí náà ló wà fún eni tí kò bòwò fún àgbà. Àlàdé (1982:140 se àgbékalè Odù Ifá kan tí ó so àtubòtán àìbòwò fún òbí àti àgbà
Bí omodé bá fé hùwà ògbójú
Tó bá rí ògbó awo kó gbá a lójú
Bí ó bá rí àgbà òsègùn kó je é níyà
Bí ó bá ri aafaa níbi tó gbé nforí balè fún Olórun
Kó dojúu re délè
A dífá fún àwíìgbó
Omo tó ńlùgbó awo
Tí ńjàgbà sègùn níyà
Ó rí alùfáà níbi tó gbé ńkírun
Ó dojú è dé lè
Òrúnmìlà ní kí e fi sílè, ó wá fi yé won pé:
Àjepé ayé kò sí fómo tó lùgbó awo
Àtelèpé ò sí fómo tó lùgbà òsègùn
Omo tó dojú àfáà délè nibi tó gbé ńyin Olórun oba
Owó ara rè ló fi nwákú
Wàràwàrà nikú ìdin, wàràwàrà.
(Àlàdé 1982: 140)
Àlàdé ní ìmòràn fún eni ti kò bá fé kú ní wàràwàrà gégé bí odù Ifá òkè yìí se so. Ó ní Yorùbá gbà pé gbogbo eni tí ó ba ti siwájú eni dáyé ju ni lo, a sì ní láti máa bòwò fún won A kò gbodò yájú sí won nítorí enikéni tó bá fé dàgbà kò gbodò gba òpá lówó arúgbó.
Orlando sòrò lorí ìbòwò fún àgbà. Ó fi àpeere oko àti ìyàwó gba aráyé ni ìmòràn lórí ìbòwò fún àgbà. Ó se pàtàkì kí á ránti pé ipò òbí àti àgbà ni oko wà sí ìyàwó ní àwùjo Yorùbá. Yorùbá gbà pé oko ni adé orí aya. Ó ye kí oko tójú aya kí aya, sì bòwò fún oko rè. Lójó tí baálé ilé bá fé fa ìyàwó fún oko rè. Wón a so fún oko òhún pé ìtójú omo àwon di owó rè. Oko ni gbé e láti ibi tí àwon òbí ìyáwó tójú rè dé.
Kò ye ko tún ma pàse fún mi mó o ìyàwó
Kò ye ko tún je gàba lórí mi ìyàwó.
A ti sàlàyé pé oko ni olórí aya ni àwùjo Yorùbá. Ibi tí a bá ti pè ní orí a kì í fi telè. Eko ìwà omolúwàbí Orlando bí ó se hàn nínú àyolò òkè yìí, ni pé ìyàwó tí ń pàse lórí oko rè, tí ń je gàba lórí oko rè kì í se ìyàwó rere, béè ni kì í se omolúwàbí.
Okorin yìí tún sòrò díè lórí ìbòwò
Bí bèbí ti dára tó ó fìwà bewàjé
Bí sisí ti dára tó ó fìwà bewàjé
Omo dára kò mà dè níwà alákorí
Òkorin fi yé wa pé ìyàwó tí kò bòwò fún àgbà, alákorí ni, omoge tí ó dára tí kò ní ìwà kò kógo já, kò sì le jé omolúwàbí. Òkorin yìí tún sòrò lórí ohun tí àìbòwò fún àgbà lè fi odìndi orílè èdè sé se. Bí àpeere
Ìwà àìfàgbà-féníkan ò jáyé ó gún
Ká mu kúrò níwáa wa
Ohun tólúkálukú máa je ló ń wá
E jé kí Nàìjíríà o tòrò
Nínú àyolò òkè yìí Orlando sàlàyé pé Nàìjíríà gégé bí orílè èdè kò tòrò. Níwòn ìgbà tí ó jé pé ara orílè èdè Nàìjíríà ni ilè Yorùbá wà, a jé pé, a kò fi àgbà fún enìkan. Eni ti a bá gbà ní àgbà, ó di dandan kí á bòwò fún un. Lójú tiwa, àkíyèsí òkorin yìí tònà nítorí ibikíbi ti kò ba ti si ìbòwò fún àgbà, yálà nínú ebí, agbo ilé, ìlú, ìjoba ìbílè, ibi isé, ibi eré, ìjoba ìpínlè tàbí Nàìjíríà lápapò, kò le sí ìlosíwájú níbè.
Bákan náà ni òrò rí ni àwùjo àwon Hausa. Ààyé pàtàkì ni òrò ìbòwò fún àgbà wà. Òwe Hausa kan so pé ‘Bin na gaba bin Allah’. Èyí túmò sí pé kí á bòwò fún Olórun àti ènìyàn. Hausa gbà pé a gbódò bèrù Olórun àti ènìyàn. Èyí sí gbodò han nínú ònà tí à ń gbà bòwò fún won. Tí a bá ń sòrò ìbòwò fún àgbà ní àwùjo Hausa, kì í se eni tí ó bí wa nìkan ni a ní lókàn bí kò se gbogo eni tí ó ba ti jù wá lo.
Dan Maraya sòrò lórí ipò tí ìbòwò fún òbí àti àgbà wà ni àwùjo Hausa:
Da farken Allah ne gaba
Manzon Allah na biye
To uwa da uba sunna biye
(Lákòókó, Olórun ni asiwájú gbogbo èdá
Òjísé Olórun ni àtèlé
Baba àti ìyá ló tún tè lé é)
Nínú àyolò yìí, Dan Maraya se àgbékalè ètò ìbòwò bí ó se wà ni sísè-n-tèlé ní àwùjo Hausa. Olórun se àkókó, òjísé Olórun se èkejì nígbà ti bàbá àti ìyá se èketa. Ó se pàtàkì kí á rántí pé a kò le rí Olórun sójú, a kò sì le rí òjísé rè tí se Ànábí. Bàbá àti ìyà nìkan ni won jé èdá alààyè tí wón se é rí sójú. Ní kúkurú, ohun tí Dan Maraya ń so ni pé bàbá àti ìyá ni ó ye kí á bòwò fún jù.
Àgbékalè rè yìí bá àwùjo Hausa mu púpò nítorí ètò ìbòwò fún àgbà àti òbí fesè múlè púpò débi i pé ó sòro púpò fún omodé láti wo àgbà lójú. Èyí fe se àkóbá díè fún ìjoba tiwa-n-tiwa tí ó wà ní orílè èdè Nàìjíría ní apá òdò àwon Hausa. Èyí rí béè nítorí bí àwon asiwájú won gan-an ń se asemóse, ó nira fún won láti kó irú asiwájú béè ní ìjánu. Àgbékalè ètò ìbòwò fún àgbà yìí ní àwùjo Hausa tún hànde nínú ohun tí ó ń selè ní àsìkò tí àwon aláwò funfun gòkè wá. Bì ó tilè jé pé won se àgbékalè ìjoba tuntun ni apá ilè Yorùbá àti ti Ìgbò síbè won kò se béè ní àwùjo Hausa nítorí wón gbà pé enu àgbà tí wón jé asiwájú àwùjo won ran ilè dáradára.
Dan Maraya tún sòrò lórí ìbòwò fún òbí àti àgbà:
Idan ka haifi danka
Ka ka ai shi gun karatu
Ika I sa koyariwa kowanikuna
Ika I sa I yanke farce
Sai sa I wanke rigahulada wando
I je aji ka gane
Sannan I zan karatu
(Nítorí bí a bá bí omo
A gbé e lo sí ilé èkó
Tisa yóò máa fi ojoojúmó
Kóo bí a ti ń gé èékánná
Bí a se n fo èwù, sòkòtò àti fila
Tísà yóò ko ní àwon ìwà rere
Àti íbòwò fún obi
Nínú orin yìí, Dan Maraya je kí á mò pé Tísà a máa ko omo ni ìmótótó, isé ilé síse àti ìbòwò fún òbí. Èyí fi hàn pé àwon tísà jé agbáterù èkó ìwà omolúwàbí. Ìrànlówó pàtàkì ni èyí je fún àwùjo.
Tí a bá wo ìgbàgbó àwùjo méjéèjì lórí ìbòwò fún àgbà bí ó se hàn nínú ìtókasi tí àwon òkorin méjéèjì se. Ó hàn pé ohun tí à ń retí láti òdò omolúwàbí nínú àwùjo méjéèjì. Àfojúdi ni òdìkejì íbòwò. Kò sí ònà ti aláfojúdi fi lè jé omolúwàbí nínú àwùjo méjéèjì.