Itan Igbesi Aye Dan Maraya Jos
From Wikipedia
Ìtàn Ìgbésí Ayé Dan Maraya Jos
Adamu Wayya ni orúko tí Dan Maraya Jos ń jé. Bí òrò rè se rìn ló fa kí ó máa je Dan Maraya. Ìlú Buruku ní ìpínlè Plateau ni won ti bí i ní odún 1946. Olórín oba ni bàbá rè nígbà tí ó wà láyé, ó pé omo àádórin odún kí ó to filè bora bí aso. Kò pé púpò ti bàbá re kú tí ìyá re náà fi ayé sílè. Ó se ni láàánú pe Dan Maraya ko tí ì fi omú sílè nígbà tí ìyá rè kú. Ìdí abájo nìyí tí ó fi ń jé Dan Maraya tí ó túmò si omo pínnísín tó tún je omo òrukàn.
Ó gbé pèlú Oba ìlú Bukuru ó sì lo sí Ilé kéwú. O tilè ka ìwé de kíláàsì kejì ni Ilé ìwé alákòóbèrè kí ó to di pé Oba yìí kú tí kò sì sí eni tí yóò se alábòójútó rè mó. Ó bèrè sí tèlé àwon eléré kan káàkíri ìgbèríko. Arábìnrin kan ti orúko rè ń je Mamu ni olórí àwon òsèrè òhún. Lára àwon tí ó tún wa nínú ìkò òhún ni àwon omo Mamu méjì Audu àti Idi. Ilù kan soso péré ni egbé osere òhún ni.
Nínú ìrìnkiri won, wón de ìlú Bauchi níbi tí Dan Maraya ti rí ‘Kuntigi’ (ohun èlò tí a fi igi àti okùn tín-ín-rín se, ó dà bí i gìtá òde òní. A gbó pé kòròfo ìsáná, ìrùkèrè àti orísìí igi kan tí ń jé ‘Kebasi ni Dan Maraya fi se ‘Kuntigi’ àkókó tí ó lò. Títí di òní olónìí ‘Kuntigi’ yìí nìkan ni Dan Maraya ń lò nínú orin rè. Kò pé púpò tí ó fi kúrò léyin Mamu ati àwon omo rè tí ó sì ń tèlé Audu Yaron-goge. Léyìn èyí ó tilè fi ìgbà kan tèlé àwon awakò. Omo odún méèédógún péré ni nígbà ti ó gbé àwo orin rè àkókó jáde tí ó pè ní ‘Karen mota’ èyí tí ó tumo si ‘omo èyìn òkò’ (Salihu 2004:12).
Lásìkò tí wón ń fi oyè Òmòwé dá Dan Maraya lola odun 1996, àwon aláse Yunifasiti ti ìlú Jos sàlàyé pé ó wu Olorun ló fún Dan Maraya ní èbùn orin kíko. Bí ó tilè jé pé okorin ni bàbá rè, kò dàgbà dé ibi kan tí bàbá re fi kú, ko di ìgbà tí ó kó isé orin lódò enìkan kí ó tó korin. Ìlúmòóká olórin ni Dan Maraya. Òkìkí re si ti kàn káàkiri àgbáyé, ó tí korin káàriri òkè òkun. Òun sì ni olórin àkókó ni orílè èdè Nàìjíríà tí ilé isé rédíò ilè Gèésì (B. B. C. ) kókó gbà lálejò pé kó korin láìsepé a kàn ń lu awo orin lásán.
Àwon onísé akadá láti orílè èdè Nàìjíríà, Ghana, Britain àti ‘Germany’ ni won ti se isé lórí àwon orin rè láti gba oyè onímò ìjìnlè. Lára àwon oyè tí wón ti fi dá Dan Maraya lólá ni amì èyè ìjoba àpapò ‘Federal Republic Medal’ ni 1977, Member for the Order of the Niger (M. O. N.) ni 1982; United Nations Peace Award’ ni 1983; ‘Nigerian Institute of Public Enlightenement’ ni 1987 àti University of Jos Doctorate Degree Award ti 1996. Nínú ìfòròwánilénuwò ti Agbese se fún Dan Maraya ni odún 2006, ó sàlàyé pé Olórun fi àwon omo dá òun lolà. Ó ní àwon omo òun wà ni Ilé-ìwé, wón sì ń gbìyànjú nínú èkó won. ó ní bí ó tilè jé pé kò si omo òun kankan tí ó ní ìfé sí orin kíko, òun ti kó òpò ènìyàn ní orin kíko.
Lórí ìdí tí kò fi gbé àwo orin tuntun jáde mó, ó ni àrùn tí ń se ogójì ní ń se òódúnrún ohun tí ó ń se Aboyade, gbogbo olóya ní ń se. Ó ní àwon olórin ti won ti pe dáadáa bí òun, Ebenezer Obey, Suny Ade, Oliver de Coque ati Osadebe kò gbé àwo jáde mó nítorí àwon tí ń jalè ìmò àti isé oníse (pirates). Ó ní òun ní tó orin méjìlélógóta ní ìpamó ti ‘oun kò gbé jáde nítori àwon olè òhún. Ó ro ìjoba kí wón wá nnkan se sí i.