Ojo Iwaju Eko Ijinle Yoruba
From Wikipedia
OJÓ IWÁJÚ ÈKÓ ÌJÌNLÈ YORÙBÁ
Ìbà àwon Akódá,
Ìbà èyin Asèdá,
Mo kÉégún,
Mo kí Ato.
Ohun tó jé kí kókó òrò yìí je mi lógùn láti gbé síta fún àgbàyèwò èyin àgbà-òmòràn ni wí pé:
Omo tí àná bí
Ni òní ń tójú lówó
Omo tí òní bá sì bí
Ní òla yóò rí gbé pòn.
Sùgbón bí omo-òní kò bá dápé
Tí bá ya dàgèdèluná, sùègbè
Alárùn tàbí a-dákú-mùko-òsán
Ikú yóò já a gbà mó òla lówó
Yóò sì di àgbégbìn àti ìgbàgbé
Bí abéré tó bo sonù sí kànga.
Làbárè àsamò mi yìí ni wí pé àwa ènìyàn ìwòyí gbódò be okàn wa sí irú ònà èbùrú tí a lè gbà tí ìmò ìjìnlè nípa èdè àti àsà Yorùbá yóò fi túbò máa fi gbòngbò múlè tó béè ti yóò fi wúlò fún àwon ìran yìí àti ti ìran tó ń bò. Bí béè kó, bí ìgbà tí ènìyàn ń fi ìwò ni inú àmù ni aáyan àti wàhálà àwon asaájú wa gbogbo yóò já sí lórí sé náà; pàápàá jù lo ni nnkan bí ogójì odún sí àkókò tí a wà yìí ti àwon tó mò nípa àsíírí nnkan ìbílè dunjú bá ti wolè sùn tán tí àwon olùwádìí ìjìnlè èdè àti àsà Yorùbá kò sì rí eni ké gbàmígbàmí tò lo mó.
Yàtò sí wí pé a ń gbe ara eni gun esin aáyan, èdè Yorùbá gégé bí èka èkó ti di igi àlóyè, ó sì ti di aràbà láàrin èdè tiwa-n-tiwa ní apá iwo oòrùn-Afíríkà. A lè topa orírun ìmò ìjìnlè nínú èdè Yorùbá dé odún 1945 nígbà tí àwon òyìnbó amúnisìn ìgbà náà gbé ìgbìmò méjì kan dìde-ìgbìmò-Eliot at Asquith - láti rí sí bóyá ó to súnà tàbí kò ye láti dá ilé Èkó Yunifásítì si ilè wa. Àwon kan ta kò ó sùgbón a dúpé pé àwon kan fi owó sí i. Báyìí ni won da Yunifásítì Ìbàdàn sílè níbi tí òwó àwon akékòó àkókó ti kókó kàwé gboyè nínú èdè Yorùbá ní odún 1969. Kì í se odún yìí ni isé tó bèrè nípa ìwádìí nnkan ìbílè. Sùgbón èso isé àwon onímò saájú àkókò yìí àti léhin àkókò yìí ti mú kí a ra ògòòrò àwon òjògbón tí won ti to ìtàkùn èka ìmò èkó Yorùbá gòkè àgbà. Bí imi esú sì ni ìwé lórí àsà pò lójà. Ti ewì àti èdè kún ori àte pèlú. Sùgbón òpá tí a gbé lé èjìká ni òrò yìí, tèyìn tí aò rí gùn ju ti iwájú tí a ń wò lo. Àní ó tún kù ni ìbon ró.
Ó dàbú eni wí pé ìlànà èkó èdè Yorùbá ye ni àgbéyèwò bí a bá fé kí o peregedé, kí ìmò èkó náà si so irú èso tí àwon asaájú ní lókàn. Irú àtúnse báyìí ni kò ní jé kí àsà àjèjì lè gba òde òsán lówó tiwá nígbà tí àwon àgbààgbà tí won ń to pooro ìsèse Yorùbá bá ti kojá sí ibùgbé ayérayé tán, tí ó si ku àwon arungún omo òde òní nikan lókè èèpè gégé bí àgbà. Kí àlàyé wa lè baà gúnlè, e jé ki a se àkàwé èka èkó èdè Yorùbá pèlú àwon èka ìmò èkó yòókù. Èyí kì í se wí pé mo ń wo aago aláago sisé, sùgbón bí e bá rántí wí pé omi kì í sun kan ara won, kó má sùn wo inú ara won, àpeere tí n o gbé kalè yìí kò ní dàbí àsìso.
Bí a bá wo àwon akékòó ìmò sáyénsì, ìmò èro, èkó aré orí òdàn, èkó nípa ìsègùn, jógíráfì abbl., a ó rí i wí pé won ni àkókò kan tí won yà sótò fún àmúlò tàbí ìdánwò tíórì inú èkó won. Èyí ni won ń pè ní Practical kò ye kí èkó èdè Yorùbá lè dá èko tirè náà fún ajá; ó ye ki irú àkókò àmúlò èkó báyìí lè wà fún àwon akékòó tó bá fé kékòó gboyè nínú èdè Yorùbá. Èétirí? Ohun tí o so èyí di òràn-an-yàn ni wi pè o sé e sé kí a rí eni tí ó gba oyè ni Yunifásíti nínú èdè àti Lítírésò Yorùbá ki irú eni béè máa ni àtinúdá nípa ohùn enu Yorùbá kankan rárá láìjé wí pé o wòwé tàbí sín òkorin tí kò le fìdí ìgò ko “o” je. Ó ye kí ààyè wà fún kíkóni ní àgbékalè òrò láwùjo níwòn ìgbà tó jé wí pé àwùjo sòròsòrò ni orí dá ni si. Isé takuntakun ni láti jé lámèétó, sùgbón fífi ààyè sílè fún ìdánniwò àti ìkóni ní àgbékalè òrò láwùjo pèlú ogbón lámèétó yóò mú ki ìmò gbòòrò sí i.
Ni irú àkókò àmúlò èkó yìí, àwon akékòó yóò ni ànfààní láti rí púpò nínú onírúurú omo iya ìlù-gbèdu, àgbá, bàtá, àti béèbéè lo, won yóò sì tún mo gbogbo ìbátan tí ìlù dùndùn ni. Ó ye kí won mo eyo kan lù, kí won sì mò ón jó, ó kéré tán, won yóò tún mo bí a se ń ta òwú sèkèrè, bí a se ń re aró àti bí a se n se ose. Otí sèkèté àti àgàdàgídí náà ye ní kíkó. A lè pa ìwònyí pò kí ó je kóòsì kan. Yóò mú kí èkó tí a ń ko ní ìtumò sí i ju àkósórí-ko-sílè se ni púpò ilé èkó gíga tó wà nílè wa lónìí lo.
Bí òkú èkó kan bá kú tàbí tí àríyá kan bá selè ni agbo ilé kan lónìí, tí akékòó èdè Yorùbá kan sì wà níbè, àwon akékòó tí kò sí ni èka ìmò èkó Yorùbá yóò máa wo onítòhún bí eni tó ye kí o mo púpò nínú ijó ìbílè jó, kí gbogbo ohun ìsèdálè Yorùbá sì fi inú rè se ibùdó sùgbón ìrètí riú àwon eni béè yóò sákìí nígbà tí akékòó yìí bá dáhùn wí pé adìe ni òun nínú ijó ìbílè sùgbón tí ó wá dágbo ijó REGE tàbí SÓÒLÙ (Èyí tí won máa ń jo bí enu ègún gún lésè) ti ó wa di òkòtó-fijó-sàrà-dá. A tilè tún rí púpò “omo egbé” akékòó ìjìnlè Yorùbá ti kìí fé rí imí orin àti ijó ìbílè lákìtàn. Bóyá “àìtà” isé yìí ni kìí jé kí elòmìíràn fé farahàn pé akékòó èdè Yorùbá lòun àti pé bóyá wón rò pé isé àwon òle ni. A ó ménu bá èyí ní iwájú.
Díè nínú àwon ònkàwé mi yìí kò ni dunnú sí àbá tí mo ń dá yìí nítorí pé wón gbà pé èbùn ni gbogbo nnken. Ohun tí mo fé fò lésì sí irú èrò yìí ni wí pé ènìyàn kò lè lo kó èkó nípa jógíráfì kí o so wí pé èbùn ni àwòrán yíyà jé nítorí náà òun kò ní bá won lówó sí i tàbí ki ènìyàn wà ni èka èkó eré ìdárayá kí ó so pé òun kò ní bá won lówó sí òkìtì títa, nítorí pé eni tí ara rè bá rò nìkan ló le ta á. Ó dájú pé kò sí ìgbà tí irú enu béè kò ní kú sónà bí à jo nítorí won yóò so pé ó ti rí i, nígbà osùn télè kí ó tó fi kóyán. Ó tún ye kí a mò wí pé nígbà tí èkó bá dun àwon akékòó Yunifásítì lára gbóngbón, tí ó sì to àwon túlè ilé èkó àwon olùkóni-àgbà lára já gààràgà ni won yóò lè kó omo ni ilé ìwé girama àti olùkóni. Èyí yóò sì jé kí àwùjo wa tòòrò nitorí àwon ìpéèré wa yóò nífèé sí àsà àti ìse baba won, èyí tó gbára lé ìwà omolúwàbí.
Èkó èdè Yorùbá kúkú ta! Èèyàn tó bá so wí pé òwú kò tó erù, ìwòn ìba tí olúwaarè yóò fi tanná ló mú mu. Bí a ti rí nínú àwon tó kó èkó nípa òfin, ìmò èro àti ti ìsègùn ti kì í fé sisé lábé ìjoba ni a ó rí àwon eni tó bá ní ìfé sí ìlù lílù, otí ìbílè pípon, ìjálá sísun, àti béèbéè lo ti won yóò dá isé tiwon sílè.
Mo fé kí o ye wa pe àwon ènìyàn tó nífèé si àwon nnkan wònyí wà, won yóò sì tún máa pò sin i tí won yóò parapò dá egbé sílè láti di onísé àdáni tàbí kí won máa fi isé mìíràn se àbòsé lásán. Nípa báyìí, ohun àjebí iran Yorùbá kò ní lè paré bí èéfín sìgá. Torí pé nígbà tí ònà mìíràn bí tún wà tí owó ń gbà wolé fún eni tó bá kó isé náà yanjú yàtò sí owó osù, ìwúrí yóò wà fún àwon òdó láti yà síbè.
Àwon akékòó kò ní sàìbi mi léèrè wí pé níbo ni a ó ti rí àkókò fún irú isé yìí níwòn ìgbà tí ó jé wí pé a ń ba gàmbàrí jà lówó, ò tíì dá a, enìkan tún wa n bà ni dámòràn àtidá Tápà dúró, njé ìyonu ńlá kó ló fé kó ni sí? Béè ko o! A kò sàìmò pé kì í se Yorùbá nìkan ni a máa ń kó bí ó tilè jé wí pé èdè Yorùbá ni a yàn láàyò ní ilé èkó gíga. A lè fi àkókò àmúlò-èko rópò díè nínú àwon àjùmòrìn-isé tí a ńse ní kowo-ma-dilè wònyí nítorí lójú tèmi, kò wúlò tó èkó àti ànfààní iyebíye tí a lè rí nípasè ìlànà tí a ń dá lábàá yìí.
Owó ńkó? Gbòngbòn ni òrò yìí kan àwon ìjoba nítorí pé won kò gbodò sahun owó bí won bá fé jagun àjàlà lórí kí èkó tí a ń kò ní Nàìjíríà ní ìtumò. Irú owó béè ni a ó fi ra àwon èròjà gbogbo tí a nílò tí a ó sì fi gba àwon tó mo isé yìí dunjú. Won ìbáà jé púrúntù; títí tí a ó fi rí alákòwé tó lè gbé-e-tán pèlú ìmò ìwé tí ó ni.
Ó ye kí àwon alase ilé èkó giga wá ààyè bí àtikó èdè ìbílè Nàìjiríà mìíràn ní ilé èkó gíga yóò se wáyé. A ní àwon onímò nínú èdè Haúsá àti Igbo ti won lè wúlò fún èyí. Èyí yóò ran ìmò wa lówó nípa èdè, púpò nínú ohun tó sókùnkún nínú edá èdè tiwa laa lè rí ìmólè si.
Àwon alase ilé isé rédíò àti Telifísàn náà kò gbodò kèrè láti máa fi ijó, orin ìbílè hàn ju ti àwon òyìnbó lo; ki won sì máa fi eré àti ohun ìbílè polówó ojà. Bí èyí bá jé lemólemó, kò ní pé tí àsà àti nnkan ìbílè yóò fid i kòríkòsùn fún àwon èw; nítorí pé lójúmo toní ti ó mó yìí, “ará oko” ni ń wo àgbáda “eni tí kò bá Iajú” lo n dirun. Sùègbè si ni ènìyàn tó ba ń lo ahón ìbílè.
Ònà ebùrú mìíràn tí alè gbà bí a bá fé kí àsà ìbílè Yorùbá ó múmú láyà àwon ìpéèrè wa ni pé kí gbogbo ilé-ìwé gíga kòòkan máa ya ojó kòòkan sótò lódoodún gégé bí ojó àmúsògo àsà ìbílè. Ni irú ojó yìí, olúkúkúlùkù ènìyàn yóò wo aso ìbílè tàbí hu gbogbo ìwà tó je mó tìbílè. Irú ìsògo nínú àsà báyìí yóò fa àsà ìbílè wa gbogbo yo kúrò nínú ògbun àìnísàlè tó gbé ń sùn, tó ń han oorun báyìí.
Bí irú àyípadà yìí bá le wáyé, ìwòn ni a ó máa kó owó goboI lé rékóòdù àti aájò ewà ara tó je ti ìlú òkèère lórí mo. Nípa báyí orò ajé ilè wa yóò fìdí múlè nígbà tí owó rékóòdù India àti fíìmù Améríkà bá ń gbe owo Ògúndáre Fóyánmu àti ADE LOVE.
Ìlànà WÀEEKÌ nínú èdè Yorùbá kò kún ojú ìwòn tó. Lójú tèmi, ó dàbí eni pé ònà tí àjo olùdánniwò náà ń gbà dán omo wò lórí èdè Yorùbá kò kún ojú ìwòn tó. Ó ye kí ìdánwò náà gbòòrò sí, nípa pípèsè àwon ìbéèrè tí yóò jé èyí-je-èyi-kò-je. Èyí yóò je kí ìbéèrè máa wáyé lórí gbogbo ìmò àti ìhùwàsí èdè Yorùbá, yàtò sí kí a kàn ka ìwé méjì kí a so pé a ti gbáradì. Èyí ń mú kí akékòó kórìíra èka èkó èdè náà bí má jèlé; kò sì tún fi ààyè sílè láti mo omo tó káre gan-an.
A tún lè so wí pé ònà tí a ń gbà láti gba akékòó wolé sí ilé èkó gíga Yunifásítì fún èkó èdè Yorùbá kò kún ojú ìwòn tó. Níwòn ìgbà tí a so wí pé a ti gba òmìnira, kò ye kú ó je wí pé èdè òyìnbó ni a ó fi máa se òpá òdíwon kí a tó gba akékòó wolé níwòn ìgbà tí a ti so wí pé a ti gba òmìnira. Fífi èdè òyìnbó se àsùnwòn lónà báyìí n fi àjùlo hàn, ó sì mú èdè tiwa lérú. Béè ìbí kìí ju ìbí; bí a ti se bi erí laa bí omo. Bí akékòó kan bá ní páàsì onípèkeje nínú èdè Òyìnbó (nítorí wí pé òun ni èdè àmúlò-isé) tí isé tó sì ti yege dáadáa bá pé márùn-ún. Ó ye kí o wolé si ilé Èkó gíga pàápàá jùlo láti kó èdè Yorùbá. Se bi èdè òyìnbó ló fi ko ìyóókù. Tóò! àbá lásán lèmi ń dá o. Bí mo ba jáko je, e se é ni omodé kì í mo èko je kí o ma yi i lénu. Yóò see se o! Wálé Abíódún