Jiji Owo Gbe
From Wikipedia
Jíjí Owó Mèkúnnù Gbe Lo Si Òkè Òkun
Ní géré tí àwon ológun ti lé àwon olósèlú tí wón gba ètò ìjoba lówó àwon òyìnbo amúnisìn ni orílè èdè yìí ti wo wàhálà kí àwon olórí máa kówó je. Lópò ìgbà òkè òkun ni wón sábà n kó irú àwon owó wònyìí lo. Òkan kò sé òkan ni òrò àwon ìjoba òhún títí di àsìkò yìí. Ni báyìí gómìnà ìpínlè méjì ni wón ti fèsùn kan pé wón ba òbítíbitì owó lówó won ní ilè òkèèrè.
Gégé bí ìwé ìròyìn Daily Sun ti ojo kejì osù kejìlá odún 2005 se so, òkan nínú won tilè sa mo àwon òyìnbó lówó nípa mímúra bí obìnrin. Owó kò tilè tí ì máa té àwon asiwájú oníjégúdújerá yìí tí Orlando fi ké gbàjarè. Ní àsìkò ìjoba ológun Buhari tí Orlando gbé àwo yìí jade yen àwon díè tí wón jé agbódegbà won ni owó tè: Bí àpeere,
Lílé: Wón ti kò gbogbo kàlòkàlò
Tó ń kó wa lówó ní Nàìjíríà
Òpòlopò ń sèwòn nítorí owó Nàìjíríà o mo wí o
Ègbè: Ùbéfu ò nákó nana yeyè
Sùbùnàdò ò nákó nana yeyè
Lílé: Òpò òsìsé won ra mótò sónà repete
Opò òmòwé, wón pé ra won ni Director
Opélopé oba Èdùmàrè ló ń tójú wa ní Nàìjíríà ò
Ìyàn ìbá ti pànìyàn torí owó wa tón ko lo o baba o
Òtìto ni òrò tí Orlando so nínú àyolò oke yìí. A wòye pé ìwà jegúdú jerá yìí wà ní ààrin olósèlú àwùjo Hausa. Àkíyèsí wa ní pé ó sòro fún àwon òdómodé àwùjo Hausa láti wo ojú àgbàlagbà. Bóyá èyí ni ó fa sábàbí dídáké tí òpòlopò okorin ilè Hausa dáké títí kan Dan Maraya.
Ní àwùjo Yorùbá ìgbàgbó wa ni pé, oba kì í pa òkorin, bí ó tilè jé pé a rí àwon àpeere díè níbi tí òkorin ti dáràn lówó àwon olórí (Adédèjì 1981:231). Èyí kò fi gbogbo ara rí béè ní àwùjo Hausa, Ó sì se àkóbá díè fún òrò ìsèlú won nítorí kò sí ìkóra-eni-ní-ìjánu.