Itan Igbesi Aye Dan Maraya Jos

From Wikipedia

Ìtàn Ìgbésí Ayé Dan Maraya Jos

Adamu Wayya ni orúko tí Dan Maraya Jos ń jé. Bí òrò rè se rìn ló fa kí ó máa je Dan Maraya. Ìlú Buruku ní ìpínlè Plateau ni won ti bí i ní odún 1946. Olórín oba ni bàbá rè nígbà tí ó wà láyé, ó pé omo àádórin odún kí ó to filè bora bí aso. Kò pé púpò ti bàbá re kú tí ìyá re náà fi ayé sílè. Ó se ni láàánú pe Dan Maraya ko tí ì fi omú sílè nígbà tí ìyá rè kú. Ìdí abájo nìyí tí ó fi ń jé Dan Maraya tí ó túmò si omo pínnísín tó tún je omo òrukàn.

Ó gbé pèlú Oba ìlú Bukuru ó sì lo sí Ilé kéwú. O tilè ka ìwé de kíláàsì kejì ni Ilé ìwé alákòóbèrè kí ó to di pé Oba yìí kú tí kò sì sí eni tí yóò se alábòójútó rè mó. Ó bèrè sí tèlé àwon eléré kan káàkíri ìgbèríko. Arábìnrin kan ti orúko rè ń je Mamu ni olórí àwon òsèrè òhún. Lára àwon tí ó tún wa nínú ìkò òhún ni àwon omo Mamu méjì Audu àti Idi. Ilù kan soso péré ni egbé osere òhún ni.

Nínú ìrìnkiri won, wón de ìlú Bauchi níbi tí Dan Maraya ti rí ‘Kuntigi’ (ohun èlò tí a fi igi àti okùn tín-ín-rín se, ó dà bí i gìtá òde òní. A gbó pé kòròfo ìsáná, ìrùkèrè àti orísìí igi kan tí ń jé ‘Kebasi ni Dan Maraya fi se ‘Kuntigi’ àkókó tí ó lò. Títí di òní olónìí ‘Kuntigi’ yìí nìkan ni Dan Maraya ń lò nínú orin rè. Kò pé púpò tí ó fi kúrò léyin Mamu ati àwon omo rè tí ó sì ń tèlé Audu Yaron-goge. Léyìn èyí ó tilè fi ìgbà kan tèlé àwon awakò. Omo odún méèédógún péré ni nígbà ti ó gbé àwo orin rè àkókó jáde tí ó pè ní ‘Karen mota’ èyí tí ó tumo si ‘omo èyìn òkò’ (Salihu 2004:12).

Lásìkò tí wón ń fi oyè Òmòwé dá Dan Maraya lola odun 1996, àwon aláse Yunifasiti ti ìlú Jos sàlàyé pé ó wu Olorun ló fún Dan Maraya ní èbùn orin kíko. Bí ó tilè jé pé okorin ni bàbá rè, kò dàgbà dé ibi kan tí bàbá re fi kú, ko di ìgbà tí ó kó isé orin lódò enìkan kí ó tó korin. Ìlúmòóká olórin ni Dan Maraya. Òkìkí re si ti kàn káàkiri àgbáyé, ó tí korin káàriri òkè òkun. Òun sì ni olórin àkókó ni orílè èdè Nàìjíríà tí ilé isé rédíò ilè Gèésì (B. B. C. ) kókó gbà lálejò pé kó korin láìsepé a kàn ń lu awo orin lásán.

Àwon onísé akadá láti orílè èdè Nàìjíríà, Ghana, Britain àti ‘Germany’ ni won ti se isé lórí àwon orin rè láti gba oyè onímò ìjìnlè. Lára àwon oyè tí wón ti fi dá Dan Maraya lólá ni amì èyè ìjoba àpapò ‘Federal Republic Medal’ ni 1977, Member for the Order of the Niger (M. O. N.) ni 1982; United Nations Peace Award’ ni 1983; ‘Nigerian Institute of Public Enlightenement’ ni 1987 àti University of Jos Doctorate Degree Award ti 1996. Nínú ìfòròwánilénuwò ti Agbese se fún Dan Maraya ni odún 2006, ó sàlàyé pé Olórun fi àwon omo dá òun lolà. Ó ní àwon omo òun wà ni Ilé-ìwé, wón sì ń gbìyànjú nínú èkó won. ó ní bí ó tilè jé pé kò si omo òun kankan tí ó ní ìfé sí orin kíko, òun ti kó òpò ènìyàn ní orin kíko.

Lórí ìdí tí kò fi gbé àwo orin tuntun jáde mó, ó ni àrùn tí ń se ogójì ní ń se òódúnrún ohun tí ó ń se Aboyade, gbogbo olóya ní ń se. Ó ní àwon olórin ti won ti pe dáadáa bí òun, Ebenezer Obey, Suny Ade, Oliver de Coque ati Osadebe kò gbé àwo jáde mó nítorí àwon tí ń jalè ìmò àti isé oníse (pirates). Ó ní òun ní tó orin méjìlélógóta ní ìpamó ti ‘oun kò gbé jáde nítori àwon olè òhún. Ó ro ìjoba kí wón wá nnkan se sí i.