Kiko Yoruba bi Ede Akokunteni

From Wikipedia

kiko Yoruba bi ede Akokunteni

Egbé Akómolédè (2001) Kíkó Yorùbá Bí Èdè Àkókúnteni Ibadan; University Press Plc. ISBN 978 030 527 0

ORÒ ÀKÓSO

A fi ara balè ko òwó ìwé yìí ní ìbámu pèlú Kòríkúlóòmù tuntun tí Ilé-Isé Ìwádìí àti Ìdàgbàsókè Èkó ní Nàìjíríà (National Educational Research and Development Council) se fún kíkó èdè Yorùbá bí Èdè Àkókúnteni ní ilé-ekó sékóńdìrì kékeré ní Nàìjíríà. Sùgbón nígbà tí a pàjùbà òwó ìwé náà tán, ó hàn kedere pé won yóó tún wúlò fún àwon tí won nífèe sí kíkó èdè Yorùbá kún èdè tiwon, tí won kì í se akékòó ní ilé-èkó sékóńdìrì kékeré ní Nàìjíríà.

Lára àwon tí a rí pé yóò tún se béè wúlò fún ni: àwon akékòó ní ilé-èkó sèkóńdìrí àgbà ní Nàìjíríà tí won kò ní ànfààní Oníp kejì, kóléèjì Eń siì lì àti irúfé àwon akékòó béè ní Yunifásítì ní Nàìjíríà. Bákan náà ni òwó ìwé yìí tún wà fún àwon àgbà tó ti mò-ón-ko-mò-ón-kà ní èdè mìíràn ni Nàìjíríà tàbí ní orílè-èdè mìíràn ní àgbáyé, tí won nílò láti mo èdè Yorùbá múlò fún tí wón bá ń kó elédè mìíràn.

Àwon omo Egbé Akómolédè àti Àsà Yorùbá Nàìjíríà tí ó ní ànfààní láti lówó sí kíko òwó ìwé yìí dúpé gidigidi lówó Egbé náà fún yíyàn tí a yàn wón; wón sì dúpé lówó ilé-isé Asèwétà Universtiy Press PLC. Bákan náà, a kò le sàì dúpé lówó Olútùú èdè Yorùbá ilé-isé náà, Adéolá aya Fáléye fún akitiyan won lórí gbígbé òwó ìwé náà jáde lónà ó wú ènìyàn lórí.

Ibi tó bá kù sí, a ó máa sé àtúnse rè lójó iwájú ní agbára Olódùmarè, Eni kan soso tí isé owó Rè péye. Ní báyìí, a kè sí yín, ará ilé, èrò ònà, e bá wa fi òtító-inú àti ìfé pípé gba obè yìí; kí e tó o o wò; kí e sì so fún wa bí ó se rí lénu yín o.

Ire Kàndù!