Eko nipa Omoluwabi ati Ihuwasi
From Wikipedia
ÒWÓOLÁ SHERIFAT ABÍMBÓLÁ
ÈKÓ NÍPA ÌWÀ OMOLÚÀBÍ ÀTI ÌHÙWÀSÍ
Yorùbá bò, wón ní “ilé làá tí i ko èsá rode”. Ohun tí Yorùbá gbà pé ó jé omólúàbí po púpo. Ó bèrè láti ibi èkó ilé títí tí ó fi dé órí aájò síse. Àwon obí maa ń kó àwon omo won bí a se ń hu ìwà láwùjo.
Láti ìgbà ìkókó ni won ti máa ń bèrè nítorípé àwon àgbàlagbà máa ń so pé kékeré lati ń pa èèkan ìrókò tí ó bá dàgbà tán apá kò ní káa.
Àkókó nínú ètò omolúàbí ni ìkíni jé. Yorùbá gbàgbó pé eni tí kò bá mo ènìyàn kíí, kò yàtò sí ìlábòrò baba òbo. Láti ìgbà tí omo bá ti wá ní pínnísín ni àwon òbí rè yóò ti kó o ní àsà bí a se ń kí ènìyàn. Kìí wá se omode nìkan ní ó gbódò máa se ètó rè nípa ìkíni yìí. Tomodé tàgbà, oba àti ìjòyè, olówó àti mèkúnnù ni ó pon dandan fún láti pa àsà yìí mo ní ilè káàárò o ò jíre. Ìkíni máa ń wáye láti orí kíkí òbí eni títí tí ó fi dé orí kíkí oba. Èyí ni ó fi iteríba hàn, Yorùbá bo won ní gbùrùgburu làá yí kàá, gbòrògboro, làá da ìdòbálè, ka dòbálè ká pàgbón mó, ó maa ń ládúrú ore tíí se fún ni. Orísìírísìí ni ìkínì àti ìgbà tí à ń kìni ní ilè Yorùbá, bí omo bá jí ní òwúrò, bí ó bá jé okùnrin yóò dóbálè gbalaja, bí ó bà sì jé obìnrin, yóò kúnlè wòò. Bí a se ń kíni ní àárò yàtò sí òsán, tí òsán sì yàtò sí ti alé. Omo tí kò bá mo èèyàn kí, irú omo béè yóò gba àbùkù.
Nínú àwon ìwà omolúàbí ni ìbòwò fún àgbà wà. Bí ènìyàn bá fi ojó kan ju elòmìíràn lo òwò ojó kan náà yóò wà lára rè títí ojó ogbó. Bí Yorúbá bá sì so pé pàpànlagi tàbí ìpánnlè ni enìkan, àìní ìbòwò fún àgbà ni wón ń tóka sí ní ara rè. Bí àgbàlagbà bá ń jeun po pèlú omodé, ó ní bí omode gbodò se jókòó pèlú ìwà ìrèlè àti ìbòwò fún àgbà. Omodé kò gbodò fè níwájú àgbà, béè sì ni kò gbodò sáájú mú eran.
Omolúàbí gbódò jé eni tí ó ń fi ara balè gba ìmòràn tí àgbà ba fún-un, bí ó bá sì se àsìse, tí wón bá tókà sí èsè rè fún-un, ó gbódò túúbá. Ara ohun tí Yorùbá fi ń mo omolúàbí ni ìwà ìtìjú. Yorùbá gbà pé enikéni tí kò bá ní ìtìjú, kìí se omolúàbí àti pé orísìírísìí àrùn ni yóò wa lára eni béè. Eni tí ó bá ní ìtìjú kò ní puró, kò ní jalè, kò ní seke àti béè béè lo.
Ibi tí a tun tile rí ìwà omolúàbí ni ìbòwò fún àwon oba alayé. A máa ń kí oba níti òwò àti iyi pèlú ìforíbalè. A kì í so òrò àbùkù tàbí ìsokúso ní ààfin oba àìjébèé, inú túbú ni olúwarè yóò ti bá ara rè. Nítorí èyí ni àwon Yorùbá fi máa ń so pé “Aróbafín ni Obá á pa”.
Ara ìwà omolúàbí ni ìsòrò sí láwùjo. Òrò tí won ò bá pe ènìyàn sí, a kìí dá sí i. Bí àgbàlagbà bá ń sòrò, omodé kìí da síi àfi ìgbà tí ìgbàláàyè bá wà fún-un. Àgàgà tí ó bá jé ìpádé ebí, ayò títa, ìpàdé ode àti béè béè lo.
Yorùbá bò wón ní “Àgbà to se isu to dáa je, yóò da erù rè gbé délé ni”. Ara ìwà omolúàbí ni kí omo kékeré rí àgbàlagbà tí ó gbé erù sórí tí ó sì sáré lo gba erù náà lórí rè, irú omo béè ni à ń pè ní omolúàbí, ó sì pon dandan fún irú àgbàlagbà náà láti fún omo náà ní nnkan èbòn. Ohun mìíràn gégé bíi omólúàbí ni iran-ara-eni-lówó. Bíi kí ègbón ran àbúrò lówó, kí àbúrò ran ègbón lówó, kí àwon òré méjì ran ara won lówò. kí á má hu ìwà ìmo tara eni nìkan. Tí a bá rí eni tí ó kù díè káàtó fún, kí á se ìrànlówó fún irú eni béè.
Ìwoso àti ìmúrasí ènìyàn náà se pàtàkì, ó sì máa ń fi irú eni tí ènìyàn jé hàn. Obìnrin nílè Yorùbá kò gbodò fi ihòhò ara rè sílè tí ó bá ń jáde síta. Béè náà ni ti okùnrin náà, wón gbódò múra bí ó ti ye. Sùgbón ó se ni láàánú pé ní ayé òde òní, òpòlopò obìnrin ni wón ń wo àkísà tí wón ní àwon ń wo aso béè náà ni àwon okùnrin tí wón fi yetí sí etí, wón sì ń di irun orí won bíi ti obìnrin.
Láwùjo Yorùbá, tí ànfààní kan bá yojú, eni tí ó bá jé omolúàbí ni won ó fún ní irú ànfààní náà nítori pé wón á ní “òun làwon le fi ògún rè gbárí, òun làwon sìlè fí owó rè sòyà. Nítórí náà, nínú gbogbo àsà Yorùbá ni ìwà omolúàbí ti se pàtàkì “won á ní omo ènìyàn àtàtà kìí sìwà hù, omo tí kìnìún bá bí, ìwà bí oba bí oba kò ní jínà sí i”.
ÌTÓKA SÍ
Àwon Àsà Àti Òrìsà Ilè Yorùbá láti owó o Olú Dáramólá B.A. (LOND) àti Adebáyò Jéjé.
Ìwé Àsà ìbílè Yorùbá láti owó o Olóyè Olúdáre Olájubù.