Ise Asewo
From Wikipedia
Aséwó Síse
Orísirísìí isé ni ó wà ní àwùjo Hausa. Àwon isé wà tí ènìyàn lè fowó gbáyà pé ohun ni òun ń se. Èdá lè dárúko isé àgbè, ode, àgbède, àárù abbl. Ó sòro fún èdá láti so pé isé asèwó tàbí isé olè ni isé òun. Èsìn mùsùlùmí kórira sìná síse. Ìbálòpò ààrin tokotìyàwó nìkan ni èsìn yìí fara mó. Àwón agbáterù èsìn yìí mò pé ara kì í se òkúta, ìdí nìyí tí wón se fi ara mo àsà kí okùnrin tètè ni ìyàwó àti kí obìnrin tètè ni oko.
Àkíyèsí tiwa ni pé ilé ìtura tí ó ní àwon aséwó pò púpò ní ilè Hausa. Bí ó tilè jé pé a lè rí irú àwon ilé ìtura béè ní àwon ìlú ńlá ńlá bí Èkó, Ìbàdàn abbl ní ilè Yorùbá, irú àwon ilé ìtura yìí kò wó pò ní àwon ìlú kéékèèkéé.
Eni tí a bá pè ní omolúwàbí ní àwùjo Hausa kò le jé eni tí ń ná ilé aséwó. Ìyàwó ni irú èdá béè yóò fé. Ó tilè le fé tó ìyàwó mérin. Dan Maraya ménu ba òrò àwon aséwó pé;
Karuwa ta gan Karen mato da kudi
Ya ka taho malam na baya
Ga ruwa can, zo ka yi wanka
Ga mayafi dinga rufa
Arnen ya arce da mayafi
Na-innako ya tsere da bokiti
Gagon ya shafa da kudi
Ke ma gaba kyankara iyar banza
(Aséwó ri owó lówó omo èyìn oko
Jòwó wá nibi ògbéni èyìn
Gbé omi kí o lo we
Gba aso yìí kí o dà bora
Omokómo sálo taso ìbora taso ìbora
Ó tún gbé róbà ìwè sá lo
Béè ni kò sanwó aséwó
Iwo aséwó, se o ó tun se àsìse yìí léèkan sí i
Nínú àyolò òkè yìí, òkorin ménú bá àwon ìwà kan ti omolúwàbí kò gbodò hù. Ìwà afibisólóoré ni omo oko hù. Ó wo ilé asewó¸wón gbé omi ìwé fún un pèlú aso ìbora. Ó wè tán, kò sanwó òyà fún aséwó, ó tún jí róbà ìwè àti àso aséwó lo. Òkorin yìí fi òkò kan pa eye méjì ni. Ó bu enu àté lu ìwà olè àti. Ìfibusólóore ti omo oko hù. Ní apá kejì ó jé kí á mò pé kò sí èrè nínú isé aséwó. Aséwó inú àyolò yìí pàdánu owó òyà àti dúkìá tí ó ti ní télè.
Ní ayé tí àrùn éèdì ti gbòde, owó ribiribi ni ìjoba ń ná láti se ìponlongo pé kí àwon ènìyàn kó ara won ni ìjànu nípa ìbálòpò takotabo. Ònà kan pàtàkì tí àìsàn yìí fi ń ràn ni nípa ìbálòpò takotabo. Tí àwon omo okò àti àwon onísekúse mìíràn bá síwó ílé aséwó yíyún, ti aséwó náà gba pé òfò wà níbè àtipé aséwó kì í gbayì láwùjo, àrùn éèdì àti àwon àrùn mìíràn tí ó fara pé e yóò dínkù ní àwùjo.
Wàhàlà gidi ni òrò isé aséwó je ní àwùjo àwon Hausa. Òpòlopò ile fàájì ti otí bá ti wà ni àwon aséwó wa. Wón ni otí ìbílé tí ń jé bùrùkùtù, òpò àwon tálíkà won ni wón féràn otí yìí. Òpò èmí ló ti run nípa wíwakò léyìn otí mímu. Òpo ebi ló ti túká nígbà ti Baálé ilé bá ti fi owó oúnje àti owó ilé-ìwé àwon omo mu bùrùkùtù. Ní odún 2002 òpò àwon ìpínlè tí ó wà ni ilè Hausa ni wón gbé òfin ‘Sharia’ inú èsìn mùsùlùmí kalè òfin yìí kò fara mó otí mímu àti sìná síse. Ìjìyà ńlá ló wà fún arúfin títí dé orí egba jíje àti ikú. Òpòlopò àwon aséwó ni a gbó pé won ti sá wá sí apá ònà Àbújá àti àwon ìpínlè tí kò se ofin ‘Sharia’.
Àkíyèsí tiwa ni pé irú wá ògìrì wá pò ni àwùjo Hausa. Àwon aséwó mìíràn tilè wá láti àwon orílè èdè bí i ‘Ghana’, ‘Togo’ àti ‘Liberia’. Ní àwùjo Yorùbá, òmìnira wa fún okùnrin láti fe iye ìyàwó tí ó ba wù ú. Kì í se òrò eyo kan tàbí eyo mérin péré. Dípò à ń relé aséwó ìyàwó ni onítòhún yóò kuku fé. Bóyá òmìnira àti fé iye ìyàwó tí oníkálukú bá fé ni kò jé ki òrò aséwó síse bí isé fesé rinle láwùjo Yorùbá.
Ní báyìí, a ti rí i pé àwùjo méjì kò le wà kí ó bára mu régírégí. Ènìyàn méjì gan-an kò le bá ara mu régírégí. Bí àbúdá won bá bára mu, ìhùwàsí kò le bára mu. Dan Maraya wo àwùjo Hausa, ó gbé orin kale, ó sí se ìtókasi àwon ìwà omolúwàbí inú àwùjo rè. Orlando Owoh ní tirè wo àwùjo Yorùbá, kí ó to fi orin sè ìtókasí àwon ìwà omolúwàbí. Ìtókasi àwon méjéèjì tónà pàápàá tí èdá bá ní ìmò nípa àwùjo tí wón gbé orin kalè fún.