Iku Olokun Esin
From Wikipedia
Iku Oloku Esin
Wole Soyinka, (1994), Ikú Olókùn-esin, Ibadan, Frontline Publishers ISBN 987-2679-77-1. Ojú-ìwé 103.
Ikú Olókùn Esin
Orí àwon ìsèlè gidi ti ó selè ní Òyó, ìlú àtijó àwon Yorùbá ní ile Nigeria ni odún 1949, ni Soyinka gbé Olókùn-Esin kà. Eré náà so nípa bí Simon Pilkings, Ajélè se dá sí òrò Olókùn Esin tí kò sì jé kí ó bá oba kú. Kò fi sìkà o. Àwon ohun burúkú ló ti èyìn rè yo láàrin àwon ará ìlú àti láwujo àwon Òyìnbó. Sùgbón bí àwon èdá ìtàn aláwò dúdú ti ń forí gbá tàwon Òyìnbó, tí dúdú ń fori gbá fúnfun yìí, ohun tí ó ń se Sóyínká kojá pé “àsà ta ko ara won” lo, bi ó ti wù kí iyen ba nkan jè tó. Aseyorí tí Sóyínká se nínú eré yìí ní bí ó se wú òrò ìjìnlè àti orò síse ní ìgbésí ayé Yorùbá jáde, ayé àwon alààyè, àwon òkú àti àwon tí a kò tìí bí, àti bí ó se so ó di eré orí ìtàgé tí ó ga lólá bí eni pé òun alára wà níbè, tí ó sì fib í ó se yàtò gédégédé sí ayé àwon òyìnbó amúnisìn tí ó dòbu hàn.