Suuru ninu orin Orlando Owoh ati Dan Maraya Jos

From Wikipedia

Sùúrù

Yorùbá bò, wón ní, sùúrù lè se òkuta jinná. Wón gbà pé onísùúrù ní fún wàrà kìnìhún. Paríparí rè ni pé èdá tó ní sùúrù, ohun gbogbo ló ní. Adéoyè (1982:84-86) so ìtàn Àbàtìàlàpà tí ó jé ìkà. Májèlé ni baba àgbà ìkà yìí fi ń pa àwon ará ìletò rè. Léyìn òpòlopò ìpàdé omo kékéré kan rí ìdí agbára rè. Omodé yìí sì fi idà ahun pa ahun. Adéoyè sàlàyé pé èmí sùúrù ní àwon ará ìletò fi rí èyìn àgbà ìkà yìí. Pàtàkì àlàyé wa ni pé sùúrù ni ó lè borí ìsòro. Ó se pàtàkì kí á rántí pé ó se é se kí á rí ohun tí sùúrù lè se tí agídí kò le se sùgbón a kò le rí ohun ti agídí lè se tí ipá sùúrù kò ká. Bí èéfín se jé àmì pàtàkì fún iná ni ìjà jíjà àti gbólóhùn asò jé àmì pàtàkì tí a fi ń mo eni tí kò ní sùúrù.

Orlando sòrò lori sùúrù pé;

Akánjú tulú orán

Ò bá jé na sùúrù si

Egbèje rè kò tó í se bè

Ìràwò kò lè bósùpá tayo

Orán jé orísi olú kan tí ó máa ń hù ní ilè Yorùbá. Olú yìí kéré púpò. Tín-in-rín tín-ín-rín báyìí ni ó máa ń rí ó yàtò sí olú ewè tàbí bèje tí ó tóbi dé ibi pé tí a bá tu mérin péré, ó tó se obè. Sùgbón bí olú orán se kéré tó, a máa dùn púpò kì í tèdin bí àwon olú ńlá ńlá tí a dárúko. Àfiwé tí Orlando se níbí ni pé bí eni se sùúrù tí ó tu olú orán se ń je adùn rè ni eni tí ó bá se sùúrù ní òrò ilé ayé yóò se je ìgbádùn ayé. Àkíyèsí kejì ni pé, ó fi olú orán wé àwon olú mìíràn béè náà ni ó fi ìràwò wé òsùpá. Ó gbà pé Olórun kò da gbogbo ènìyàn bákan náà nítorí Olórun tó dá ìràwò kéré ni ó dá òsùpá tí ó tóbi. Ó ro àwon tí won fé máa sáre nípa tirè ki wón má dààmú mó. Yorùbá gbà pé eni tí kò mo ibi tí egbé rè ti là, eré ni yóò sá kú. Nínú ìgbàgbó àwùjo Yorùbá kò ye ki èdá kànjú ju elédàá rè lo rárá.

Bí a bá wo àwùjo àwon Hausa bákan náà ni omo ń sorí. Pàtàkì ni òrò sùúrù jé nínú ìwà omolúwàbí. Òwe Hausa kan so pé ‘Hakuri shi ne maganin duniya’ òmírán ni ‘Hanya lafiya, a bi ta da shekara’. Òwe kíní túmò sí pé, ‘sùúrù ni oògùn ayé, òwe kejì sì ń gba ni ní ìyànjú pé ‘kò ye kí á kánjú lá obè gbígbóná’.

Àdíìtì (Hadith) kejìdínlógún ti An-Nawawi sòrò lórí ìbèrù Olórun àti fífí rere san búburú. Nínú ìtúpalè rè ti Lemu (1993:50) se, o sàlàyè pé sùúrù jé òkan pàtàkì nínú ohun ti Ànábì Mòńmódù fi fa àwon ènìyàn wo inú èsìn mùsùlùmí. Ahmed (2000) náà kin òrò Lemu (1993:50) yìí lèyìn.

Dan Maraya sòrò nípa sùúrù nígbà tí o korin ìdárò fún olóògbé

Haladu Farin Isoho báyìí pé;

Mahaifa sun shaida

Abokai sun shaida

Haka kowa ya shaida

Ya shuka abin kirki

Akwai hakuri a wajen Haladu

Sannan ko akwai da ‘a

Bay ya rainin kowa ko

(Àsomó IX, o.i. 248, ìlà 10-16).

(Obi rè jé elerii

Àwon òré rè jé elérìí

Gbogbo ènìyàn je elérìí

Pé ó gbèrò rere, ó sì se rere

Haldu ni suuru àti ìteríba

Ó nìwà rere

Kì í fojú tenbelu enikeni

Nínú àyolò orin yìí, Dan Maraya sàlàyé pé onísùúrù èdá ni Haladu je nígbà ayé rè. Isé rere àti ìwà rere rè kò paré. Èyí ni ó jé ki òkorin yìí toro orun rere fún un. Ní àwùjo Hausa, ìgbàgbó nínú èsìn mùsùlùmí rinlè púpò. Wón gbàgbó pé léyìn ikú, àjínde wà. Eni bá fi ìwà rere se isé rere yóò lo sí àlùjóńà nígbà tí eni bá fi ìwà búburú se isé búburú yóò lo sí inú iná.

Dan Maraya tún sòrò síwájú nípa suúrù pé;

Mai –gida da uwar-gida

In an yi fada dan annabi

Don Allah a bar saurin fita

To amma in an bibiya

Wata kila gidan da munafiakai


(Tokotìyàwó e jòwó

Tí ìjà bá wà

Nítorí Olórun, e má se yára bínú

Bóyá tí e bá se ìwádìí dáradára

Àwon agbótekusoféye kan wà ní agboolé)

(Àsomó 10b, o.i. 266-267, ìlà 12-16).


Nínú àyolò orin yìí , òkorin ń gbìyànjú láti fi yé wa pé sùúrù ni a fi ń soko obìnirin. Eni tí a bá ń so fún pé kí ó má se yára bínú. Ohun tí a ń so ni pé kí ó se sùúrú. Eni tí kò bá ní sùúrù kò le se ìwádìí òrò ó sì sòrò fún eni tí kò le se ìwádìí láti rí òkodoro òrò. Ó ye kí á máa rántí pé ohun a fi èlè mú kì í bàjé, ohun tí a ba fi agbára sòro mú, koko ní le.

Ní àwùjo Hausa, àkíyèsí fi hàn pé ògòòrò ènìyàn a tètè máa bínú. Kí á tó séjú péé elòmíràn á ti fa òbe yo. Béè náà ni òrò rí nínú ètò ìgbeyàwó won Ìyàwó tí a sìn terùterù lè ti di ilémosú léyìn osù méta pére. Àpeere ìyorísí inú fùfù yìí ni Dan Maraya rí tí ó fi so nínú orin rè pé kí èdá máa se sùúrù. Bí a bá wo àwùjo Yorùbá àti Hausa. Ààyè pàtàkì ni àwon méjèèjì fi òrò sùúrù sí gégé bí ìwà omolúwàbí. Àkíyèsí wa ni pé àìmúsùúrù ti dá òpò wàhálà sílè nínú àwùjo méjèèjì. Àlàyé tí a se lórí ìforísónpón òpò ìgbéyàwó ní àwùjo Hausa ti bá àwon àwùjo ìlú ńlá ńlá ilè Yorùbá bí Èkó àti Ìbàdàn mu. Itó ni òpò àwon omo Yorùbá fi ń mo ilé ìgbéyàwó won kí á tó séjú pé é ìrì á ti wó irú ilé béè.

Yàtò sí òrò ìgbéyàwó, òpò ni àìnísùúrù lórí òrò owó wíwà ti gbé dé ogbà èwòn, ogunlógò si ti lo sí òsun òsán gangan. Kò sí ìyàtò kan pàtàkì nínú – ìwà àwon awakò ìlú Èkó ati ìlú Kano, tí ó bá kan òrò sùúrù, ànìnísùúrù á sì fa sún keere fà keere okò ní ààrin ígboro. Irú àwon àkíyèsí wònyí ni àwon okorin méjèèjì se ti won fi gbìyànjú láti fi orin won pàrowà fún aráyé.