Iwe Iroyin

From Wikipedia

Iwe Iroyin

T.A. Olunlade

Litireso Alohun

T.A. Olúnládé (2005), Ìlò Lítírésò Alohùn Yorùbá nínú Ìwé-Ìròyìn Yorùbá láti Odún 1859 sí 1960’., Àpilèko fún Oyè Ph.D, DALL, OAU, Ifè, Nigeria.


[edit] ÀSAMÒ

Isé yìí dágbá lé wíwo ìlò lítírésò alohùn Yorùbá nínú ìwé-ìròyìn Yorùbá. Ìwádìí náà se àyèwó ìlò lítírésò alohùn Yorùbá tí a rí fà yo nínú ìwé-ìròyìn Yorùbá láti odún 1859 dé 1960. Síse àwárí àwon ìlò lítírésò alohùn yìí ràn wá lówó láti wo àkóónú àwon ìwé-ìròyìn ojó pípé wònyí. Ìwádìí yìí wo ipa tí ìlò lítírésò alohùn yìí ní lórí àwùjo yìí. Isé yìí se àgbéyèwò, ìpínsísòrí àti àlàyé fínnífínní nípa akitiyan àti àtinúdá àwon ònkòròyìn pàápàá nípa àmúlò orísìírísìí lítírésò alòhùn Yorùbá bó se hàn nínú àwon ìwé-ìròyìn. Ònà tí a gbà se isé yìí ni pé a wá ogún ìwé-ìròyìn Yorùbá tí wón jáde láàrin odún 1859 dé 1960. Ìwádìí ní yààrá ìkàwé àti yààrá tí a se àwon ìwé pàtàkì lójò sí ni a fig be ìwádìí yìí lésè. A se èkúnréré ìwádìí lódò àwon àgbà tí wón ni òye àsìkò tí àwon ìwé-ìròyìn wònyí jáde. A se ìtúpalè àwon àkójopò èdè-fáyèwò tí a rí láti inú ìwé-ìròyìn tó je mó ìlò lítírésò alohùn pèlú tíórì ìmò ìbára-eni-gbé-pò ajemó lítírésò. Ìwádìí wa fìdí rè múlè pé lítírésò alohùn Yorùbá bí oríkì, àló onítàn, òwe, ìtàn àtinúdá àti àbáláyé, àwàdà, èèwò àti orin ni àwon oníròyìn àsìkò tí a yàn lò. Ìwádìí yìí jé ká mó pé orísìírísìí ònà ni àwon oníròyìn gbà lo lítírésò alohùn. Ònà mókànlá ni àwon akòròyìn gbà lo oríkì nínú àwon ìwé-ìròyìn. Won tún lo orísìírísìí lítírésò alohùn mìíràn ni ìlànà wònyí. Wón lo àwon kan ko àkolé àti olú-àkolé ìròyìn, won fi òmíràn ko ìtàn-ìgbésí-ayé-eni àti àkomònà, wón sì fi òmíràn gbé àwàdà kalè fún èrò àwùjo. Ìwádìí náà tún fi hàn pé orin ni ònkòròyìn mìíràn fi bá èrò àwùjo sòrò. Ìwádìí yìí tún jè ká mò pé àwon oníròyìn se àtinúdá àti àdàko lítírésò alohùn Yorùbá láti se ìbánisòrò pèlú àwon èrò àwùjo ti wón lè ka ìwé-ìròyìn Yorùbá nígbà náà. Ní ìparí, a rí èrí tó pò pé lítírésò alohùn Yorùbá tí a lò níní ìwé-ìròyìn Yorùbá wúlò fún ìkónilékòó àti ìdánilárayá láwùjo Yorùbá. Èrí tó móyán lórí sì fi hàn pé tawo-tògbèrì ní ń se àmúlò lítírésò alohùn Yorùbá saájú àti léyìn ìgbà tí wón ń ko nnkan sínú ìwé-ìròyìn. Ìwádìí wa fìdí rè múlè pé ìlò lítírésò alohùn láwùjo Yorùbá ni ó se okùnfà lítírésò alákosílè láwùjo Yorùbá.

Alábòójútó: Òjògbón T.M. Ilésanmí

Amúgbálégbèé Alábòójútó: Òmòwé Bòdé Agbájé Ojú-Ìwé: 516



[edit] Oju-iwe Keji

T.A. Olúnládé (2005), Ìlò Lítírésò Alohùn Yorùbá nínú Ìwé-Ìròyìn Yorùbá láti Odún 1859 sí 1960’., Àpilèko fún Oyè Ph.D, DALL, OAU, Ifè, Nigeria.


ÀSAMÒ

Isé yìí dágbá lé wíwo ìlò lítírésò alohùn Yorùbá nínú ìwé-ìròyìn Yorùbá. Ìwádìí náà se àyèwó ìlò lítírésò alohùn Yorùbá tí a rí fà yo nínú ìwé-ìròyìn Yorùbá láti odún 1859 dé 1960. Síse àwárí àwon ìlò lítírésò alohùn yìí ràn wá lówó láti wo àkóónú àwon ìwé-ìròyìn ojó pípé wònyí. Ìwádìí yìí wo ipa tí ìlò lítírésò alohùn yìí ní lórí àwùjo yìí. Isé yìí se àgbéyèwò, ìpínsísòrí àti àlàyé fínnífínní nípa akitiyan àti àtinúdá àwon ònkòròyìn pàápàá nípa àmúlò orísìírísìí lítírésò alòhùn Yorùbá bó se hàn nínú àwon ìwé-ìròyìn.

Ònà tí a gbà se isé yìí ni pé a wá ogún ìwé-ìròyìn Yorùbá tí wón jáde láàrin odún 1859 dé 1960. Ìwádìí ní yààrá ìkàwé àti yààrá tí a se àwon ìwé pàtàkì lójò sí ni a fig be ìwádìí yìí lésè. A se èkúnréré ìwádìí lódò àwon àgbà tí wón ni òye àsìkò tí àwon ìwé-ìròyìn wònyí jáde. A se ìtúpalè àwon àkójopò èdè-fáyèwò tí a rí láti inú ìwé-ìròyìn tó je mó ìlò lítírésò alohùn pèlú tíórì ìmò ìbára-eni-gbé-pò ajemó lítírésò.

Ìwádìí wa fìdí rè múlè pé lítírésò alohùn Yorùbá bí oríkì, àló onítàn, òwe, ìtàn àtinúdá àti àbáláyé, àwàdà, èèwò àti orin ni àwon oníròyìn àsìkò tí a yàn lò. Ìwádìí yìí jé ká mó pé orísìírísìí ònà ni àwon oníròyìn gbà lo lítírésò alohùn. Ònà mókànlá ni àwon akòròyìn gbà lo oríkì nínú àwon ìwé-ìròyìn. Won tún lo orísìírísìí lítírésò alohùn mìíràn ni ìlànà wònyí. Wón lo àwon kan ko àkolé àti olú-àkolé ìròyìn, won fi òmíràn ko ìtàn-ìgbésí-ayé-eni àti àkomònà, wón sì fi òmíràn gbé àwàdà kalè fún èrò àwùjo. Ìwádìí náà tún fi hàn pé orin ni ònkòròyìn mìíràn fi bá èrò àwùjo sòrò. Ìwádìí yìí tún jè ká mò pé àwon oníròyìn se àtinúdá àti àdàko lítírésò alohùn Yorùbá láti se ìbánisòrò pèlú àwon èrò àwùjo ti wón lè ka ìwé-ìròyìn Yorùbá nígbà náà.

Ní ìparí, a rí èrí tó pò pé lítírésò alohùn Yorùbá tí a lò níní ìwé-ìròyìn Yorùbá wúlò fún ìkónilékòó àti ìdánilárayá láwùjo Yorùbá. Èrí tó móyán lórí sì fi hàn pé tawo-tògbèrì ní ń se àmúlò lítírésò alohùn Yorùbá saájú àti léyìn ìgbà tí wón ń ko nnkan sínú ìwé-ìròyìn. Ìwádìí wa fìdí rè múlè pé ìlò lítírésò alohùn láwùjo Yorùbá ni ó se okùnfà lítírésò alákosílè láwùjo Yorùbá.

Alábòójútó: Òjògbón T.M. Ilésanmí

Amúgbálégbèé Alábòójútó: Òmòwé Bòdé Agbájé

Ojú-Ìwé: 516