Isedale Yoruba

From Wikipedia

Isedale Yoruba

Ìtàn Àkoólè Yorùbá

Gégé bí ìwádìí Àtàndá (1980), bí àwon Yorùbá se dé orílè-èdè Nàìjíríà àti àsìkò tí wón tèdó síbè kíi se ìbéèrè tí enikéni lè dáhùn ní pàtó nítorí pé àwon baba nlá won kò fi àkosílè ìse àti ìtàn won sílè gégé bí àjogúnbá.

Àwon ìtàn àtenudénu tí a gbó nípa ìsèdá yàtò sí ara won díèdíè. Ìtàn kan so fún wa pé àwon Yorùbá ti wà láti ìgbà ìwásè àti láti ìgbà ìsèdá ayé. Ìtàn òrùn pé kí ó wá sèdá ayé àti àwon ènìyàn inú rè. Ìtàn náà so fún wa pé Odùduwà sòkalè sí Ilé-Ifè láti òrun pèlú àwon emèwà rè. Wón sì se isé tí Olódùmarè rán won ní àsepé. Nípasè ìtàn yìí, a lè so pé Ilé-Ifè ní àwon Yorùbá ti sè, àti pàápàá gbogbo ènìyàn àgbáyé.

Ìtàn mìíràn tí a tún gbó so fún wa pé àwon Yorùbá wá Ilé-Ifè láti ilè Mékà lábé àkóso Odùduwà nígbà tí ìjà kan bé sílè ní ilè Arébíà léyìn tí èsìn Islam dé sáàrin àwon ènìyàn agbègbè náà. Àwon onímò kan nípa ìtàn ti ye ìtàn yìí wò fínnífínní, wón sì gbà wí pé bí ó tilè jé pé ó se é se kí àwon Yorùbá ní ìbásepò pèlú àwon ará Mékà àti agbègbè Arébíà mìíràn kí wón tó sí kúrò, ibi tí wón ti sè wá gan-an ni íjíbítì tàbí Núbíà. Àwon onímò yìí náà gbà pé Odùduwà ni ó jé olórí fún àwon ènìyàn yìí.

Kókó pàtàkì kan tí a rí dìmú ni pé Odùduwà ni olùdarí àwon ènìyàn tí ó wá láti tèdó sí Ilé-Ìfè gégé bí ìtàn méjéèjì tí a gbó se so. Tí a bá ye ìtàn méjéèjì wò, a ó rí i pé kò se é se kí Odùduwà méjèèjì jé enìkan náà nítorí pé àsìkò tàbí odún tí ó wà láàrin ìsèdá ayé àti àsìkò tí èsìn Islam dé jìnna púpò sí ara won. Nítorí ìdí èyí a lè gbà pé nínú ìtàn kejì ni Odùduwà ti kópa. Ìdí mìíràn tí a fi lè fara mó ìtàn kèjì ni pé léyìn àyèwò sí ìtàn ìsèdálè Yorùbá fínnífínní, ó hàn gbangba pé Odùduwà bá àwon èdá Olórun kan ní Ilé-Ifè nígbà tí ó dé ibè. Àwon ìtàn kan dárúko Àgbonmìrègún tí Odùduwà bá ní Ilé-Ifè. Èyí fihàn pé kìí se òfìfò ní ó ba Ilé-Ifè, bí kò se pé àwon kan wà níbè pèlú Àgbonmìrègún. Èyí sì tóka sí i pé a ti sèdá àwon ènìyàn kí òrò Odùduwà tó je yo, nítorí náà, kò lè jé Odùduwà yìí ni Olódùmarè rán wá láti sèdá ayé gégé bí a ti gbó o nínú ìtàn ìsèdá.

Lónà mìíràn èwè, a rí èrí nínú ìtàn pé Odùduwà níláti gbé ìjà ko àwon òwó ènìyàn kan tí ó bá ní Ilé-Ifè láti gba ilè, àti pàápáà láti jé olórí níbè. Ìtàn Móremí àjàsorò tí ó fi ètàn àti èmí omo rè okùnrin kan soso tí ó bí gba àwon ènìyàn rè sílè lówó ìmúnisìn àwon èyà Ùgbò lè jè èrí tí ó fìdí rè múlè pé Odùduwà àti àwon ènìyàn rè ja òpòlopò ogun kí wón tó le gba àkóso ilè náà lówó àwon òwó ènìyàn kan tí wón bá ní Ilé-Ifè gégé bí ìtàn