Ikola
From Wikipedia
ADEWON ADEDAYO
ÌKOLÀ ALÁBE NÍ ILÈ ADÚLÁWÒ
A dá Ìgbìmò (IAC) sílè láti dojú ìjà ko àwon àsà ìbìlè tí ó lánu, tí o sì wà ní Ogójìi orilè èdè. Ìgbìmò yí ikola alábe fún àwon òdóbìnrin wa sí etígbo o ìjoba aláwòdúdú, béè ná à ni egbé àwon obìnrin aláwòdúdú nílè Africa tí a mò lédè gèésì sí “African women’s networks àti àwon ìgbìmò àgbáyé míràn bii Mandalaeo Ya warawake ni Kenya, sùgbón tí ó wà ní Nàìjíríà báyìí àti egbé akítùn obìrin tí a mò lédèè gèésì sí “New woman” ni ile Egipiti tí wón sì kakun ara ètó o won.
Àwon egbé wònyí mú òrò òmìnira obìnrin lókùnkúndùn, ńwón ńlàkàkà láti dékun ìfojú téńbélú u àwon obìnrin.
Ní ìpàdé àkójopò àwon orílè èdè kerin toríi àwon obìnrin tí ńwón sè ní ìlú u Beijingni 1995, ìgbìmò ná à ké sí ìjoba láti pàse lórí àwon òbàyéjé tí ó lòdì sí òmínira obìnrin.
Ní ìlòdì sí ìhà tí ńwón kosí àwón obìnrin òrò o, arábìnrin Fauziya Kassindja, enití ó jé omodún métàdínlógún ní ìlú u Tógò ni ńwón tún gbéyèwò nípa wipe, àwon òbí i rè fé fí tipá fún ún lóko léyì tí ó lòdì sí ìfé e tire. Fauziya, enití ó na papa bora ní òwàrà 1994 lati bégi dí ètò ìgbeyàwó àti wipe tí ó jé wípé gígé ojú u ara rè wà nínú-un àsà àti ètò ìgbeyàwó ní ìlú u rè é wà ní àtìmólé ní kété tí ó dé ilè aláwòfunfun “United States” látàríi wipe ó lo ayédèrú. Ńwón dáa sílè léyìn bí odún kan tí ńwón sì sètò ìtura fún un léyìn òpòlopò ìgbóhún sílè àti ìyàwòrán.
Orílè-èdè méjìdínlógbòn ni ón kópa nínú ìkolà alábe ní ìlú-u Áfríkà báyí, yátò sí ilè àwon gàmbàrí nílè adúláwò àti ilè ígípítì. Ìkolà alábe má a ńwáyé láàrín àwon Mùsùlùmí, Onígbàgbó àti àwon jû bí ó tile je wipe kì í se ara ilana èsìn.
Àkójopò orílè èdè tí a gbà ní àjo “Demographic and Health Survey (DHS)” tí ńwón se ní orílè èdè méfà – Central African Republic, Cote d’Ivore, Egypt, Eritrea, Mali àti Sudan. Ní orílè èdè wònyí, àjo “DHS” mú-u yéwa wipe bíi etàlélógójì sí ètàdínlógórùń-un obìnrin ní a ti kola alábe fún. Ní àwon ìlú wònyi ipa ìkolà alábe ò dógba, ní èyí tí ó jé wipe, bíi obìnrin èrìnléláàdórun ní ó ti kola alábe ní ìlú u Mali, sùgbón ní Tamaseki métàdínlógún péré ni.
IRÚ-U ÌKOLÀ ALÁBE TÍ Ó WÀ
Bí ó tile jé wipe ìkolà alábe má a ńwáyé ní kókó àbí lódòó tàbí àkókó ilóyún obìnrin. Àsà yí máa ńwáyé nígbàtí omobìnrin bá wà ní omodún mérin sí méjìlá. Àkójopò DHS múu yéwa wípé láti osù méjì sí odún méfà ni àsà yí leè wáyé ní ìlú-u Málì, sùgbón títí dé omodún méfà ni ilè e ígíbítì. Àwon agbèbí ló má a ńse isé ná à.
Oríìsí méta ìkolà alábe lówà ní ìmò sáyéńsì. Èkíní ni “clitoridectomy”, ni èyí tó má a ńfa gígé e “ditosis” omo obìrin, èkejì, ni gígée “clitosis àti labiaminora” eketa a sìjé “infibulation” tí ó burú jùlo, léyìn in gígée “ditosis àti labiaminora”, ńwón máa tún gé “labia majora” líti lèè jékí ojú abe tuntun ó wà, ní èyí tí ńwón o mú papò títí ó ò fi jiná, yálà nípa rírán etí i ojú abé náà àbi síso esé méjèèjì pò. Bí ojú abé náà se ńjìnà, yíó fi ojú abé kékeré bíi igi ìsáná sílè nítorí ìtò àti èjè e nkàn osù.
ÈSÌ ÌKOLÀÀ ALÁBE
Ìkolà alábe lèè fa rúkèrúdò lójú u nkàn omobìnrin bíi, àìleè tò gere nítoríi dídùn-ún ojú abé, wíwú ojú abé, ó tún lèè ba nkàn jé nínu-un rè léyìn tí egbò náà bá jiná. Èyí tí sáyéńsì ń pè ní “infibulation” lèè fa àìsàn ara olójó pípé nítorí pípadé ojú abé, òkúta á lèèdì sí ojú abé ná à, bí ojú ihò náà bá kéré nnkàn osù ú lè má já gere, leyi tí yíò fa àìleè tètè rómobí.
Gígé ohun ti sáyéńsì ńpè ní “clitosis” tí àwon èyà míràn an lèè fa àíleè gbádùn-un ìbálòpò. Fífàyà àti ìsun èjè lèè wáyé àbí kí wón fé ojú abe náà láti lèè gba dídí àrà.
Èyí tún máa ń fa àìleè gbádùn-un ìbálòpò fún okùnrin ati obìnrin.
Ìkolà alábe fún obìnrin jé lára àsà àwon ìpínlè tí ó ń kópa nínú – un rè. Ní àwon orílè èdè kàn-kan, ebí oko á san owó orí ìyàwó fún àwon ebíi re, tí ó wá so obìnrin òhun sí kòtò isé tí kò sì nì láse.
Ní ilè Sòmálíà, wón mú bíbá obìnrin nílé ní òkúnkúndùn àti iyì, àwon ebí oko rè è gbódò yèé wò síwájú ìgbeyàwó, kí ìyá oko ó sì wo ojú abé rè tí ó bá sì wà ní pípadé.
Ní àwon agbègbè kànkan obìnrin tí ó bá tii kolà máa ń rí orísìírísìí wàhálà ní èyí tí ó jé wípé, won ò ní kààkún eni tí ó ti setán ilé oko. Ní àárín àwon Samburu ní ilè Kenya, obìnrin tí ó bá ti kolà jé onísekúse, aláìkolà àti kògbókògbó obìnrin, torí ìdí èyí ìkolà máa ńwáyé lómodún mérìnlá àti márùndínlógún ní pàtàkì kín won tó gbéyàwó. Obìnrin tó ó ní “okùnrin” leò kolò tí kòbá láko, nítorí òfin filélè wípé enití ègbón rè obìnrin ò bá ti kolà kà gbodò darapò mó àwon jagunjagun.
Egbé kíkó le è móbìrin fé tètè kolà kò le deni àyésí láwùjo àti kín wón lèè kó èbùn wá sí ilé e bàbá rè.
Gégébí bàbá a kan se wípé “Yocouba”, omo mi ò lénu òrò. Èmi laláse. Èrò re ò jeyo.