Igbomina

From Wikipedia

Igbomina

A.F. Bamidele]]

ÈKA ÈDÈ ÌGBÓMÌNÀ láti owó A.F. Bamidele, UOA, Adó-Èkìtì, Nigeria

Èka-èdè Ìghómìnà jé èyà èdè Yorùbá tí àwon Ìgbómìnà ń so. Ní ilè Yorùbá lóde òní, àwon Ìgbómìnà wà ní ìpìnlè Osun àti Kwara. Àwon ìlú tí won tí ń so èka-èdè Ìgbómìnà ní ìpínlè Òsùn ní ìlá Òràngún Òkè-Ìlá àti Òrà. Ní ìpínlè Kwara, àwon ìlú yìí pò jut i Òsun lo. Ìjoba Ìbílè mérin òtòòtò ni won ti ń so Ìgbominà. Àwon ìjoba ìbílè náà ni Ìfelodun, Ìrépodun, Òkè-Èró àti Isis. Ìlú tí wón ti n so èka-èdè Igbómìnà ni ìjoba Ìbílè Ìfélódun ni Ìgbàjà, Òkèyá, Òkè-Ode, Babáńlá, Sàáré àti béè béè lo. Ní Ìjoba ìbílè Irepòdun, lára àwon Ìlú tí wón ti ń so èkà-èdè Igbómìnà ni Àjàsé, Òró, Òmù-Àrán, Àrán-Òrin. Ní ìjoba ìbílè Òkè-Èrò èwè, won a máa so Ìgbómìnà ni Ìdòfin. Ní ti ìjoba Ìbílè Isis, a rí ìlú bíì Òkè-Onigbin-in, Òwù-Isis, Èdìdi, Ìjárá, Owá kájolà, Ìsánlú-Isis, Òlà àti béè béè lo.

Olúmuyiwa (1994:2) wòye pé òkòòkan èka-èdè ilè Yorùbá ni wón ní èyà. Èyí náà rí béè fún èka-èdè Ìgbómìnà. Lóòótó, àwon ìlú tí a dárúko bí ìlú tí a ti ń so èka-èdè Ìgbómìnà máa ń gbó ara won ni àgbóyé bí wón ba ń sòrò síbè orísirísI ni èyà èka-èdè Ìgbómìnà tí won ń so láti ìlú kan sí èkejì. Èka-èdè Ìgbómìnà Òrò sì jé òkan lára èyà èka-èdè Ìgbómìnà tí won ń so ni ekùn Òrò.

Àkíyèsí: A yo isé yìí láti inú Àpilèko Émeè A. F. Bámidélé.