Buhari
From Wikipedia
FÁJÉMIRÓKÙN AKINOLÁ
MÙHAMMÁDÙ BÙHÁRÍ
(1) Ààrè Kéje orílè-èdè Nàìjíríà
(2) Lati Dìsémba ojo kokànlélógbòn odún 1983 sí ógósì ojó ketàdínlógbòn odún 1985.
(3) Èni tí ó wà níbè kí ó tó bó sórí àlééfà ni Shehu Shagari
(4) Eni tí ó tèlè e nígbà tí ó kúrò níbè ni Ogagun Ibrahim Gbàdàmósí Babangida.
(5) Odún ti a bí i: Dìsémbà odún 1942.
(6) Ìpínlè tó ti wa: Ìpínlè Katsina, orile-èdè Náíjíríà
(7) Egbé òsèlu tí ó wà: Ologun/Egbe gbogbo omo orílè-èdè Nàijíríà. (All Nigeria People’s Party)
(8) Èsìn Mùsùlùmí. Muharmmadu Buhari ti je àarè orílè-èdè Náíjíríà nígbà kàn rí. Èyí jé ní odún 1983 sí 1985. Ó tún jé òkan lára àwon olùdije fún ipò ààre tí ko rówó mú ni Epiri 19, 2003. Èyà Fúlàní ni, ó sì ní ìgbàgbó nínú èsìn Mùsùlùmí. Katsina ní ìpínlè ti idile tó ti sè wá ti wá. Ògagun Muhamadù Buhari àti Ògagun Túndé Ìdíàgbon ni wón yan láti se asáájú orílè-èdè Nàìjíríà léyìn tí àwon ológun dìtè gbàjoba lówó ààre orílè-èdè Shehu Shagari ní Dìsèmbà 31. 1983.
Buhari nígbà náà lóhùn ún ni wón yan gégé bí ààre orílè-èdè àti olórí pátápátá fún gbogbo egbé omo ogun orílè-èdè nígbà tí a fi Túndé ìdíagbon se igbákeji re. Nígbà tí won so o di aare orílè-èdè, ó fi gbogbo enu so pé ó tó kí ìgbà yípadà kúró lówó àwon ìjoba alágbádá tí wón je jegúdújerá àti pé nígbà ìsèjoba rè ni a gbé àjo Ìlúmòóká kan kalè tí wón pè ní (WAI) “War Against Indiscipline” Igbogunti ìwà kòlòbòròsí, ìwà àìbíkítà, ìwà ìbàjé péépèèpé láwùjo. Bú o tilè jé pe làbé ijoba ológun apàsé wàá ni wón ti gbé àjo yìí kalè, ìgbétasì tàbí ìpolongó yìí fesè ranle débì pé yàtò sí pé òpò ènìyàn ló mú u lò, ó sì ń nípa lórí àwon ìwa tó bétòómú tó ye kí ojúlówó omo orílè-èdè máa hu ni kòro àti ní gbangba títí di òní olónìí.
Ijoba rè nígbà náà lóhùn-ún jé èyí tí a mo bí eni mowo àmó àwon ènìyàn bèrè sí dèyìn léyìn ìjoba rè nígbà tí òun ati Ìdíàgbon bérè sí gbé àwon ìgbásè tó lekoko jù. Àwon òfin idiwon kan-n-pa (Decree) tí wón mú lò. Lára àwon òfin yìí ní pé kí ìjòba lágbára láti so ènìyàn séwòn láìlèjáde mó, láìsí sejó onítòhún, láìsí rí pé ó jé aditè ló lodi si ìjoba.
Ogagun Ibrahim Babangida ló sòtè gbajoba lówó Ogagun Mahammadu Buhari ni odún 1985 nítorí pé ó fé sèwádìí àwon owó tí wón kona lénu ise ológun. Bó bá jé pe lóòótò ni ogagun Ibrahim Babamgida sèwádìí yìí. Òpò àwon lógàlógà lénu isé ológun ni wón kó bá ní kí won kógbá sílé. Irírí yìí ló jé èyí tí ó da ogagun Muhammdu Buhari lókanru ju nínú ìtàn ìgbésí-ayé rè.
Léyìn àkókò yìí, ìgbà tí a tún gbúròó rè ni nígbà ìsèjoba ogagun Sanni Abacha. Ó sise gégé bí olórì àwon ti o bójúto òrò ìnáwó epo ronì (petroleum trust fund).
Ní odun 2003, Buhari díje fún ipò ààre lábé ìjoba alágbádá láti inú egbé (All Nigeria People’s Party ANPP). Wón fi èyin rè gbálè tàbí ó fidirémi láti owó àwon (People Democratic Party PDP). Ààrè Olúségun Obásanjo ni ó là a mólè nínú Ìbò náà. Àwon onímò ìsirò so pé èyí tí ó fi là á ju mílíònù mókànlá lo.
Ó seniláànú pé ògagun Buhari kò ní àwon ohun tó se koko láti borí ìdíje fún ipò ààre ní orílè-èdè Náíjíríà,:- fún àpeere owó ìyen àpèkánukò, àti àwon eléte tí wón lè so ogún ìbò rè di ogójì tàbí di ààdóta pàápàá. Òòtó ni pé òpò èsùn ìwà àìsóótó ni wón gbé dìde ní ilé-ejo lòdìsí ìbò náà. Àjo “Commonwealth” náà si bènu àté lu ìwà màkàrúru tí o selè nígbà ìdìbò náà síbè ohun tí won so fún Ogagun Muhammadu Buhari ní ilé ejó ni pé kí ó má fàkókò re sofo nítorí pé kò ní ohun tó pe fi ra ohun tí wón ń pé ní ìdájó òdodo. Siwájú síì wòn só fún un pé òpò omo orílè-èdè Nàíjíríà ni kò lágbára láti máa gbé pátáko “a ò lè gbà” kan kiri ojú pópó mó. Wón ní bó bá jo bíi pé ìreje wà, wón ní kó fówó wónú won ni ko fi sosùn kó fi para. Léyìn-ò-reyìn Ilé ejó wá gbé àbájáde kan jáde pé sogún dogódì tàbí Ogbón àlùmòkóróyí tó wà nínú ìbò náà kíì se ohun táa lè fowó dan-in-dan-in mú láti le mu ká fagile odindi ìbò ààre náà pátápátá. Ohún tí wón ń so ni pè èsùn tí ògagun Bùhárí gbé wá kò lése nílè tó nítorí náà, won jé kó mò láti ilé ejó pé ó fidíremi.
Ní ojo kejìdínlógún Dìsémbá 2006, Ogagun Mahammodu Buhari ni won. yan kale láti díje fún ipò ààre ní odún 2007 nínú egbé òsèlú (ANPP). Yorùbá ní bá –ò-kú ìse ò tán. Eni tí wón ń reti tí yóò je olúdije pèlú re ni odún 2007 ni eni tí o n sakoso egbé òsèlú PDP lówólówó. Ògbeni Umaru Musa Yar’adua.
Yàtò sí Ògagun JTU Aguiyi-Ironsi, Buhari jé òkan lára ààre orílè-èdè yìí to ti fèyìntì tí kò sowó ilu básubàsu. Léyìn tí won yo o kúrò nínú àhámó tí wón fí sí kò ní ilé tí ó lè dé sí. Nsé ló lo yáwó nílé ìfowo pamó tó fí ra kaadi ìdìbò fún ipò ààré tí egbé (ANPP). Èyí tí o ná an ni mílíònù méwàá náirà. Òwó ìfeyìnti rè lénu isé ológun ni òna kansoso tí owó ń gbà wolé fún un lónìí.
Ó sì wà láàyè, oun àti àwon ìdílè ré wà, tí won ń gbé ní ìpínlè Katsina nílu rè, tí ó fowólérán tí ó ń dúró dì ìgbá ìbò odun 2007