Orisa Itapa

From Wikipedia

[edit] Oju-iwe Kiini

Orisa Itapa

O.O. Ojutalayo

O. O. Ojútaláyò (1981), ‘Òrìsà Ìtàpá’ láti inú ‘Òrìsà Ìtàpá (Obàtálá) ní Ilé-Ifè’., Àpilèko fún Oyè Bíeè, Department of African Languages and Literatures, OAU, Ifè, Nigeria, Ojú-ìwé 1-5

ÌBÈRÈ ÒRÌSÀ ÌTÀPÁ

Òrìsà ìtàpá jé òkan nínú awon òrìsà ilè Yorùbá tí a gbàgbó pé ìsèdá ayé kò sèhìn in won òrìsà ìtàpá yìí se pàtàkì jákèjádò ilè Yorùbá. Ó férè má sí ìlú tàbí ìletò kan tí won kì í tí i bó ó, torí ipa tí ó ń kó ni ìgbésí ayé ayé omo èdá kò se é fi owó ré séhìn. orísìírísìí orúko ni wón fún Òrìsà Ìtàpá ní ibi tí wón ti ń bo ó. Àwon kan ń pè é ní Òòsàálá tàbí Òrìsàálá, òòsà funfun tàbí Obàtálá, won a sì máa kì í ní:

“Obàtálá bàtarìsà

Oba tapatapa lóde Ìrànjé.” OI 176

Orísìírísìí àpilèko ló ti wáyé nípa òrìsà tí a ń pè ní Obàtálá yìí, orí ìtàn àtayébáyé ni a sì gbé àwon àpilèko wònyí lé. Bí àwon Òyìnbó Olófintótó tó wá topinpin èsìn Ìbílè Yorùbá se ń ko tiwon ni omo Yorùbá ń ko, béè sì ni àwon omo Ifè kò gbéyìn nínú isé náà. Pàtàkì ohun tí a rí gbó tàbí tí a rí kà nípa Obàtálá pín sí méjì. Èyí ni ipa tí ó kó nínú ìsèdá ayé àti omo ènìoyàn. Enu kò sí pé Obàtálá nípa tó kó nínú ìsèdá omo ènìyàn sùgbón enu kò kò lórí ipa tí ó kó nínú ìsèdá ayé. Bí àwon kan ti gbàgbó pé Obàtálá ló dá ènìyàn àti ohun gbogbo tó wà ní ara rè ni ogunlógò omo Yorùbá gbàgbó pó Òbórógidi ni Olódùnmarè dá omo ènìyàn kí Obàtálá tó wá se ojú, imú àti isé onà tó kù sí i lára. Èhìn èyí ni Olódùmarè tó wá mí ìmí ìyè2 sí i lára. Ìdí èyí ni wón se ń ki Obàtálá ní:

“Ení sojú semú” OI 177

Ìgbàgbó àwon ènìyàn pín sí orísìí méta nípa ìsèdá ayé, pàápàá ipa tí Obàtálá kó nínú rè, bí àwon kan ti gbàgbó pé Obàtálá ló dá ayé àti gbogbo ohun tó wà níbè ni àwon mìíràn gbà pé Odùduwà ló dá a. Àwon kan sì gbàgbó pé Odùduwà gba isé tí Olódùmarè rán Obàtálá se mó on lówó ni nígbà tí onítòhún memu yó sùn lo sójú ònà. Èyí ó wù ó jé, káàkiri ilè Yorùbá ni a gbàgbó pé Obàtálá jé òkan nínú àwon òrìsà àkókó tó wá sáyé. Ogun lógò ló kà á kún Oba, bàbá tàbí àgbà àwon òrìsà tó kù, won a sì máa pè é ní “Obarìsà”. Torí pé a gbègbó pé òun ló dá gbogbo ènìyàn bí wón se wà ní òní olónìí yìí ni a se kà á kún “Igbákejì” tàbí “Ibikejì Olódùmarè”. Àwon tó gbàgbó pé Obàtálá se isé ìsèdá ayé ní àseyorí wí pé ojó mérin ló fi se é. Ó ya ojó karùnún sótò fún ìsinmi gégé bí ojó ti won ó máa sìn ín, tí won ó máa bo ó. Àwon tó wí pé emu àmuyó mú kí ó sùn gbàgbé isé tí Olódùmarè rán an tí Odùduwà fi eba isé náà se pín sí méjì nínú èrò won. Bí àwon kan ti gbà pé òun àti Odùduwà ni Olódùmarè rán níse àti pe ìgbà tó sùn lo ni onítòhún gba isé náà se ni àwon mìíràn gbà pé Odùduwà kò bá a lo níbèrè pèpè. Ìgbà tó sùn lo ni Olódùmarè rán Odùduwà kó lo se isé náà fún òun. Àwon mìíràn tilè wí pé Odùduwà ló toro àyè láti lo gba isé náà se lówó Olódùmarè kí onítòhún tó fún un. Bólájí Ìdòwú3 wí pé Obàtálá se isé ìsèdá ayé ní àseyorí. Èhìn náà ló gbin igi òpe, Awùn àti Dodo sí orí ilè tó dá yìí. Omi ara àwon igi yìí ni yó máa pa òùngbe tí o bá ń gbe ènìyàn, èsò rè yó sì kápá ebi tí o bá ń pa wón. Adìye ati Eyelé tó lò fún ìsèdá ayé yó máa bi si, won ènìyàn ti yó máa gbé ayé. Nígbà tó se, Obàtálá toro òjò láti òdò Olódùmarè, òjò sì bèrè sí ní í rò. M. a. Fábùnmi4 wí pé omo ìyá kan náà5 ni Obàtálá àti Oòduà láti òde òrun wá. Obàtálá ni Olódùmarè rán láti òde òrun pé kó lo dá ayé. Sùgbón nígbà tó memu yó sùn gbàgbé, Olódùmarè rán Oòduà lo gba isé náà se. Ìdí èyí ni emu se di èèwò òrìsà àti àwon àwon omìsìn rè di òní olónìí. Olóògbé J.A. Adémákinwá6 wí pé léhìn tí Olódùmarè7 fi omi pa ilé ayé ré, ó rán Oduduwa pé kó lo dá ilè tuntun sórí ìkun omi náà onítòhún sì se béè. Èhìn èyí ni Olódùmarè rán Odùduwà wá sí orí ilè tí ó dá náà ní ilé ayé. Sùgbón kí onítòhún tó wá, ó bi Ifá léèrè ebo ní rírú, àtùkèsù ní títù. Ifá ní kí Odùduwà rú èwòn kan gégé bí ebo, ó sì so ohun tí won ó se pèlú. Òrúnmìlà ni yó kókó rò sí ilé ayé tí Obàtálà yó tèle. Tí won ò bá padà sí òrun, a jé pé wón rí ibid é lé nìyen, kí Odùduwà àti àwon omo léhìn rè tèlé àwon. Ìdí èyí ni àwon omo èhìn Obàtálá se ń wí pé bàbá àwon làgbà8, tí wón sì fi ogbón àyínìke pa ìtàn dá pé bàbá àwon ni Olódùmarè kó rán nísé kí Odùduwà tó gba isé náà se mó on lówó. Phillip Stevens9 wí pé Obàtálá wà lára àwon àgbà òrìsà tó bá Odùduwà rè sí òkè Òrà nígbà tí onítòhún wá dá ilé ayé. Wándé Abímbólá10 wí pé ìrànjé àti Ifón ni a gbà pó jé ilé Obàtálá, ìdí èyí ni a se ń pè é ní òrìsà Olúfón. Sùgbón ìwádìí láti enu Awo Fátógùn fi yé mí pé òpòlopò ìlú tí Ifá sòrò nípa won ni ò sí láyé mó. Ohun tó se pàtàkì ni pé Ifè ni gbogbo òrìsà rò sí àti Obàtálá pàápàá. Ibè ni won ti tàn lo sí ìlú yòókù, èyí jásí pé Ifè ni Obàtálá ti lo sí Ifón àti Ìrànjé. M.O. fásógbón ni tirè gbàgbó pé Obàtálá bá àwon òrìsà tó kù rò sí òkè Òrà láti inú okò tí Odùduwà11 kan wá dá ayé léhìn ìgbà tí Olódùnmarè ti fomi pa ayé ré tán. Ní àárín àwon omìsìn òrìsà yìí gan-an, enu won ò kò lórí ìbèrè òrìsà won. Olóyè Omótósòó Elúyemi - Òdolé Òbàtálá, Olóyè Àpatà ti Ilé Ifè àti Olóyè Balíà Obàtálá fenu kò lórí kókó kan náà. Èyí nip é bó tilè jé pé Obàtálá ni Olódùmarè rán ní isé pé kò lo dá ilé ayé, síbè, ó memu yó sùnlo sí ìta ìlóyá, Odùduwà sì gba isé náà se món on lówó. Ìdí èyí ni àwon Ifè se ń so pé Obàtálá làgbà o, sùgbón Odùdùwà saájú è défè. Olóyè Àpatà so pé ojó ketàdínlógún tí odùduwà dá ilé ayé tan ni Obàtálá tó dé. Dídé tó dé ni ìjà so ní àárin won, Obàtálá sí bínú padà sí òrun láti lo fi ejó Odùduwà sun Olódùmarè. Ìgbà yìí ni Olódùmarè fún un ní òbe pé kó máa yá ojú, kó máa yá imú, kó sì máa se isé onà sí àwon ènìyàn tí òun bá ti dá ni ara. Èyí sì ni isé òrìsà yí í di òní olónìí. Ìdí èyí sì ni òrìsà kì í se é mu emu dòní. Olóyè Balíà gbàgbó pé nígbà tí Odùnduwà dá ilè tún, kò mo bí yó ti mò bóyá ilè náà yi tó fún títè tàbí kò yi tó. Ó gbìyànjú, sùgbón àsetì ló se é. Ìgbà yìí ni Obàtálá ti àse bo enu. ló dá alágemo. Alágemo yìí ló rin orí ilè náà wò, tó fi wón lókàn balè pé ilè tí yi tó ó rìn lórí. Ìgbà yìí ni Odùduwà àti àwon èeyàn rè tó lè rò sílè lára èwòn tí wón so mó. Ìdí èyí ni wón se ń wí pé:

Àbá alágemo bá dá

Lòrìsà á gbà.

[edit] Oju-iwe Keji

Òrò Obalésùn, olórì Àwòrò Obàtálá ní Ilé-Ifè nìkan ni ó yàtò sí èyí. Ó gbàgbó pé Obàtálá ni àkódá Olódùmarè òun ló sì kókó rè sí òde ayé12. Nígbà tó dé, orí omi ló dé lé. Ní ojó karùnún13 tó ti dé sí orí omi ló bá rán Igún, Ekùn àti Alágemo lo òdò Olódùmarè pé orí omi ni òun dé lé ni ilé ayé àti pé òtútù ń pa òun o. Olódùmarè ló fún won ní yanrìn òde òrùn tí wón dà lé orí omi náà àti adìye elésè márùnún tó tan yarìn náà ká. Alágemo ló rìn ilè náà wò bó bá yi bí kò yi títí ó fi yi tó gbé orí rè. Obàtálá ló so ibè ní Ilé-Ifè14. Ìdí èyí ni Oòni se ń ra adìyé elésè márùnún bo Obàtálá ni odoodun. Léhìn ìgbà tí àwon ènìyàn ti ń gbé ilé ayé, Ademakinwa15 wí pé oduduwa padà sí òkè Òrà, Obàtálá sì ń delé dèé gégé bí Oba. Nípa ìwà rere tí Obàtálá ń hù sí àwon ènìyàn, gbogbo won ló féràn rè gégé bí oba. Ó sòro fún won láti gba elòmíràn ni Oba won bó tilè jé pé gbogbo won ló mò pé Odùduwà Oba gidi sì ń bò léhìn. Ju gbogbo re lo, Obàtálá tún fi oríkì Ifè kún oríkì ara rè16. Báyìí ni Obàtálá fi ogbón èwé so Ilé-Ifè di ti ara rè. Èyí bí Odùduwà nínú, gbogbo ipá tó sa láti dáwó ìwà Obàtálá dúró já sí pàbó. Kàkà béè, orísìírísìí ìsòro ni Obàtálá ń mú bá ìjoba Odùduwà. Bí wón ti ń gé e lówó ló ń bo òrùka. Kèrè-kèrè òrò yìí ń le sí títí di ojó kan tí Obàtálá gbógun ti Odùduwà. Níwòn ìgbà tí Odùduwà kò ti wa ni ìmúràsílè de irú ìjà báyìí, ó pa ìwònba itú tó lè pa kó tó fesè fé e kúrò ní ààfin àti agbegbè rè pèlú ìbèrùbojo. Ní àsìkò yìí, igbó ìtàpá17 ni Obàtálá ń gbé, Obameri18 sì ń gbó àárín Ìjio àti Ìlódè. Obameri ló gba ìja Odùduwà jà, tó lé Obàtálá kúrò ni àárin ilú Ifè le si Ideta oko, tí Yemòó ìyàwó rè sì dúró sí Ita Yemòó. Sé púpò nínú àwon òrìsà ìgbà a nì ni kì í gbé pò pelú ìyàwó won. Láti dójú ti Obàtálá délè àti láti rí i pé kò yo Odùduwà lénu mó, Obameri náà kó kúrò ní ìlú, ó lo kó ilé rè sí etí ilé Obàtálá ní Ìdèta oko sùgbón ó jé kí ilé tirè sún mó ìlú jut i Obatálá lo. fún ìdí èyí, enikéni nínú Obàtálá tàbí àwon omo èhìn rè kò lè kojá sí ìlú lo se ohunkohun láìgba àse Obamerì. Sùgbón Obamérí kò fún Obàtálá àti àwon ògbóǹtagí omo èhìn rè ní àayè láti kojá sí ìlú fún ojó pipé. Òtè yìí kì ì parun dòní láàárín àwon omo Obàtálá, Obameri àti Odùduwà. Àwon omo èhìn Odùduwà àti Obamerì nìkan ni kì í lówó sí odún Ìtàpá (odún Obàtálá) bó tilè jé pé gbogbo ìlú ni odún náà kàn gbóngbón. Àsèhìnwá, àsèhìnbò, àwon omo Obàtálá di alárìnkiri sínú igbó, èyí sì mú won mo òrísìírísìí. Ìlú ewé àti egbòogi tí wón lè lò fún ànfàní ara won. Láìpé, àwon kókó be Obameri pé kó fiyèdénú ná. Ìgbà tó tó fowó wónú ni wón tó lè pe Obàtálá wá ìlú wá parí ìjà páà. Obàtálá gégé bí Olùsèdá ènìyàn kì í menu. Sùgbón Obameri gégé bí jagunjagun kò lè sàìmemu lóòjó. Láti fi Obàtálá se àwàdà ako, Onarmeri pàse fún òkan nínú àwon omo rè láti gbé agbè emu ògidì lo sí èbá ònà tí won ó gbà padà wé sí ìlú léhìn ìgbà tí wón bá ti parí ìjà náà tán. Nígbà tí wón parí ìjà náà tán, tí òun ti Obàtálá ń bò, Obameri yára ya Obàtálá sílè nígbà tó kù dèdè kí wón dé ilé rè bí eni pé ó gbàgbé ohun kan tó fé lo mú ni. Nígbà tí Obàtálá dé etí ibi tí emu wà, Obamerì pàse kí àwon omo rè fó akàngbè emu náà sí ojú ònà tí Obàtálá ní láti gbà. Emu náà pò débi pé Obàtálá ní láti gba àárín rè kojá bó tilè jé pé kò dùn mó on nínú. Ó wí pé:

“Emu kì í ti esè pa òrìsà.”

Ní odoodún ni ìsèlè yìí máa ń wáyé nígbà odún Ìtàpá. Àwon omo Obameri á da emu sí ojú ònà àwon omo Obàtálá, àwon náà à sì gba àárín rè kojá, wón á wí pé:

“Emu kì í ti esè pa òrìsà”.

Won a sì máa ko orin èébú sí ara won ní ìrántí ìjà baba ńlá a won. Phillip Stevens19 gbàgbó pé òyájú, àfojúsi àti ìgbéraga ipò rè gégé bí igbákejì Olódumarè20 ló mú kí Obàtálá jìjà àgbà pèlú Odùduwà tó jé ègbó fún un Nígbà tí Obameri lé Obàtálá lo sí Ìdèta oko fún Odùduwà tán, tí ó tún lo múlé tì í légbèé ní Ìdèta oko ni Obàtálá sá lo bá òré rè Obawumì ní Ìgbò. Onítòhún ló fi joba ní Ìgbò tó sì fún ní oríkì “Oba Ìgbò”. Ibè ló wà títí wón fi parí ìjà náà tí òun àti Obameri padà sí Ifè. Obàtálá joba ní Ile-Ifè gégé bí Oòni kerin, èhìn ikú u rè ni wón so ó di Òrìsà àkúnlèbo. Ìtàn mìíràn fi yé wa pé emu àmuyó ló mú kí Obàtálá dá ìjà ńlá yìí sílè. Adémólá Afoláyan21 so pé léhìn ìgbà tí Obàtálá memu yó se asemáse tìjósí, Olódùmarè pa á láse fún un pé kò gbodò mu emu mó sùgbón òrìsà yìí a máa jí emu mu díèdíè ní èèkòòkan. Ìgbà tó bá yó yìí ní í dá àwon eni òrìsà. Ìtàn mìíì wí pé nígbà tí Odùduwà ti jí èyí tó se pàtàkì jù nínú òkànlénígba ohun tí Obàtálá fé wá fi tún ayé se, tó sì kò láti jé kí Obàtálá rin orí ilè tó fi yèpè tó jí náà dá, Obàtálá bínú pada sórun pèlú igba tó kù. Èyí ló dá rúdurùdu sáyé. Ìbíkúbìí omo ni àwon ènìyàn ń bí, àwon omo náà ni a ń pè ní eni òrìsà lóde òní. Ìgbà yìí ni Odùduwà be Òrúnmìlà sí Obàtálá pé kó padà wá tún ayé se. Obàtálá se èyí, ayé sì padà dára fún gbobgo won. Ulli Bier22 náà jérìí sí i pé Obameri fìgbà kan lé Obàtálá kúrò ní Ifè. Sùúrù tó ní nígbà yìí ló mú gbogbo won padà wá wárí fún un gégé bí àgbà. Àwon omìsìn Obàtálá ní ilé Ifè pàápàá ménu ba ìjà yìí. Olóyè Eléyemí wí pé ìtàn àdáyébá fi yé wa pé ìjà àgbà bé sílè ní àárín Obàtálá àti Odùduwà ní kété léhìn ìsèdá ayé. Olóyè Àpatà so pé ìjà yìí ló so Obàtálá di eni tó ń yájú, tó ń yánà sí ara omo ènìyàn di òní olónìí. Alágbà Fásogbón gbàgbó pé ìjà àgbà ló rán Obàtálá lo ìgbò. Nígbà tí ìjà yìí kókó bèrè, Obawinì, òré Obàtálá bèé kó fòrò rè mo lólúmèye, kó tèle òun lo ìgbò sùgbón ó kò jálè, ìgbà tí owó Pálábà rè tó se lára igi, tí kò mókè mó nínú ogun náà ló tó sá lo Ìgbò. Ìgbà tí ìjà parí ló padà wá Ilé-Ifè, àwon tó bá a padà wá ni ó ń gbe Òkèjan ní Ilé-Ifè dòní olónìí. Ni ti Olóyè Balíà Obàtálá, àìrí àse gbà lówó Obà tálá ló mú kí Odùduwà gbógun tì í. Nígbà tí ìjà náà le, Olódùmarè pè wón sóde òrun láti parí ìjà náà. Olódùmarè pàse kí gbogbo won lo dá ènìyàn wá. Odùduwà kò kò rú ebo kó tó máa dá tirè. Fún ìdí èyí, Òbo, Ìnàkí àti gbogbo ohun tí kò dáa ló dá. Obàtálá rúbo, ó sì dá àwon ènìyàn gidi. Èyí tún bí Odùduwà nínú, ó sì tún gbógun ti Obàtálá pé pípa ni òun ó páa. Òtè yìí ló le lo sí Ìgbò, ó padà dé kó tó lo dáké sí ìyèmògún nígbà tí òtè náà kò parun. wón jà dé Òkè Èsìnmìrìn, ibè ni Obàtálá ti pa Obameri omo èhìn Odùduwà tó sì lé Èsìnmìrìn kúrò ní ìlú pátápátá. Nígbà tí ìjà parí tán, Odùduwà gbé òfìn, ó téní lé e, ó wá ránsé sí Obátálá pé òun fé bo ìpònrí òun, pé kí Obàtálá wá kí òun. obàtálá mééjì keéta, ó doko aláwo lo dífá sí bí àlo àti àbò yó ti rí. Ifá ní kí Obàtálá rí ìtì23 eku, eja àti ewúré, gbogbo re ni Obàtálá rú. Ifá tún só pé kó mú òpá òrìrè24 déní. Tó bá dé òhún, kó fi òpá òrìrè jin ilè tí wón gbéhò sí fún un. Nígbà tí Obàtálá se béè, ihò náà dí. Ó jókòó jeun, mutí, se ohun tó wùú níbè kó tó dágbére ilé. Bó ti fa òpá náà yo ni ihò débè padà. Bí Odùduwà tin í kóun jókòó lé e wò, jíjìn ló jìn sínú òfìn tí òun fúnra rè gbé sílè de Obàtálá. Báyìí ni Obàtálá ségun òtá a rè. Ìgbà tínú rè dùn tán lójó náà ló ki ara rè báyìí:

“Òsáká nìsòkò

Alápatà okùnrin

A jí sáran méegun tété

Eléyìn reyìn fún

Ekùn bè é è

Ó lémo kánú òwú bàràbàrà

Ó kòkà lójú àfòta

Àlé è bá òtá

Ghán lé e gbán ba a.

Ghan bá a ghán le è

Se é nío nnkàn25

Àríìró àlá26

Irin borokobo kán fi í bówú

A kò mó tìkà leyìn”. OI 178


Àwon omo èhìn Obàtálá ló dá egbé ìgbò sílè. Àwon tí kò fé kí Obamerì lo láìjìyà isé tó se ló ń múra lónà tó dérù ba ni wá yo Ifè lénu. Bó tilè jé pé ète àti fìyà je Obamerì ló mú won se béè, síbè, “orí yeye ní mògún tàìsè ló pò ni òrò náà dà lójó iwájú. P.H. Stevens náà kín èyí léhìn pé Ifè ni àwon Ìgbò, nígbà tó wí pé Obawinì ló ti Ilé Ifè lo dá ìgbò sílè. Alágbà Fásogbón náà kín èyí léhìn. Ó fi kún un pé àwon ì