Oju ti Ifa fi n Wo Obinrin

From Wikipedia

OJÚ TÍ IFA FÍ WO OBINRIN

Ifá je òrìsà kan pàtàkì láàárín àwon Yorùbá àwon Yorúbà gbàgbó wípé Olodumare lo ran ifá wa láti Ode Orun láti wa fi Ogbón rè tún ilé ayé se. Ogbón ìmò àti Òye tí Olódùmarè fi fún ifá ló fun ifá ní ipò ńlá láàárín àwon ìbo ile Yorùbá ….”a kéré-finú-sogbón”ni oríki ifá. Eleyi lo fi han wa gégé bí Abimbola (1969) ti gbe kala.

Nínú isé àgbékalè Ilesanmi ó wa je ki a mo wípé ifá ni alárínà fún gbogbo omo Oodua oun ni ó dabi agbenuso fún gbogbo àwon òrìsà àti Olódùmarè ohùn sì la kà sí eni to ń se àjèwò fún gbogbo mùtúmùwà. Èyí wa fún ni ibò asojú fún gbogbo àwon Irúnmolè yòókù. Aroko leti opon ifa 1998.

Ifa je ewi tí ó máà ń lo láti ilú kan sì èkejì láti dífá. Èyí lo se okùnfa bíbá òpò obìnrin pàdé ó sI fun ni ànfáàní láti fe ìyàwó púpò torí irúfé isé ti ifá ń se. Èyí sí lo fa to fi sese fún ifá láti mo ìwà won ó wú oniruuru ìwà yìí jáde torí àjosepò rè pèlú àwon Obìnrin. Ó maa ń sawo kiri ní. Gbogbo ibi tí ifá ba ti dé lo ti ń yan ìyàwó, èyí lo mu ifá rí àrísá àwon Obìnrín.

Obìnrín ní a le pè ni ìdàkejì Okùnrin tí a ba wo Tíórì Àbùdá onibeji fún àgbéyèwò lítírésò ifá tí Ilésamí pàjúbà re Tíórì yìí nì ó je kí á mo pé laisi òtún osi ko le dádúró.

Erongba opileko yìí ni láti tàn ìmólè sí ipò tí ifá fi àwon Obìnrin si Àkíyèsí àwon ipò wònyí si han nínú àwon ese ifá. Ojú méjì Òtòòtò ni ifá fi wo àwon Obìnrin

(i) Ó rí won gégé bi eni réré ti ko se maniyen to léwà.

(ii) Ifá rì àwon obìnrin ní ìdàkejì gégé bi èsù tàbí olubi èdá.

Sebí tibi tire la dálé ayé. Béè sI ni a kìí dára ka ma kù síbì kan. Àwon òbinrin la ba máà pè ní ejò gégé bí àgbékalè ifá. Nítorí ìdí èyí ifá ro àwon okùnrin láti gbón nínú gbón lode tí òrò ba ti di òrò obìnrin.

OBÌNRIN GÉGÉ BÌÍ KÒSÉÉMÀNÍ TÀBÍ ENI RERE

Nínú ìpín yìí ifá bèrè sí ni se àfihàn wón láti òde pé wón tewà ó si rí obìnrin gégé bi eni rere. Ewà won sI maa ń jeyo nínú àwò tí Olódùmarè fit a won lóre àto omu ti ó fi se àfikún ewà won. Omú tàbí oyàn obìnrin ní iyì rè ohun si ni onfa to ń fa àwon okùnrin to si ààbí èmú to ń mu won mólè lára obìnrin òdí méjì, ìjìnlè ohun Eleu ifá Apa kinni pg 54-1-3 fìdí èyí mílè pé

Funfun niyì eyin

Egun gadaaga niyi orun

Omu sìkì siki niyi obinrin

Omu sikisiki niyi obinrin pg 54 1-4

Ohun iyi àti àmúyera ní fún oko re bi èyin odi meji Obinrin ba funfun. Bakannaa ni ifá tún fi ye wa pe ki obinrin lómú ko lopin ewa. Sùgbón ìmótótó náà tún se pàtàkì láti le e perí okùnrin wale ìjìnlè ohùn enu ifá láti owo Wade Abimbola Apa kini pg 51-25-26.

Síyínka Súnyinka

Baláfúnjú ba ji a sìnyìnká sóko pg. 51 25-26.

A ko gbódò gbàgbé wipe ara ewà ita ti òrúnmìlà ri lára Àwòrán ní ó fig be e ni ìyàwó. Sùgbón ó jé ohun ìyàlénu pe bi àwòrán tí joju to ko ìwà àrokò ti ifa ń fi èyí pa ní pe ewà kii se ogbo nìkan. Bi a ti ń wo ewà ifa ni ó ye ki a naa wo ti inú.

Ifá wo ewà inú àwon obìnrin ni orísìírìsí ònà Aabo je ìrànlówó fún òrúnmìlà nigba to lalèjo meta Iku, Àrùn àti Èsù. Ààbò lo ko nnkan ìlò oko re lo ta ni ojà Ejigbomekan ní owó póókú ó ra ounje won si tójú àwon àlejò won. Ìwa ti Ààbò wù yìí mu kí àwon àlejò méétèta wònyí fì ifá sílè laipa. Won fún Òrúnmìlà ní èbùn ki won ó to fí ilé rè sílè. Inú Òrúnmìlà dun nítorí ìwà Ààbò àti ori re tí ó ko ran-an. Èyí si mu kì Òrùnmìlà feran Ààbò.

Òdá Owo awo kóro

Ààbò Obìnrin rè - pg 20 1-2

Ifá ó sI ní Ookan a a yo na

Ní Òrúnmìlà ba pé Ààbò obìnrin rè pé kí ó kó àwon nnkan ìní òun lo sójà lo tà. Ìjìnlè ohun Enu ifa iwe kinni

Ifa fe ìwà náà gégé bí aya Òle àti òbùn ayé ní ìwà je. Èyí mí ki òrúnmìlà le e lo ki lo si nnkan ò ba gún régé mó àwon ènìyàn sá lódò re. Àpónlé kò si fún òrúnmìlà mo bìí ti télè sebi ko kuku sí àpónlé fún oba tí kò ní olorì.

Ká mú rágbá

Ká fi ta rágbá

Ka mu ràgbà

Ka fit a ràgbà

Iwa la n wa o, ìwà

Alara ó ri ìwà fun mi

Ìwà la ń wa o ìwà…

Ìwà ni o je gégé bí orison áàsikí fún Òrùnmìlà sùgbón ko mo iyì ìwà àfi ìgbà tí ìwà fi ilé Òrúnmìlà sílè. Èmí náà je okan lára obìnrin òrúnmìlà. Ifá fi èmí hàn gégé bi òpómúléró. Ìdí nìyí tí Òrúnmìlà fí gbé èmí ni ìyàwó ko ba le se rere láyé. Á gbódò mò wípé emi ní ó gbé ìwá ró. LaisI èmí ko si àrà tí ènìyàn le da láyé. Aadogun, aadogbon, owó èmí ni gbogbo re wa. Àwon Yorùbá sì gbàgbó wípé èmí gígún ni san ìyà Òrúnmìlà ko le gbàgbé emí nítorí ohun rere ti èmí fún Òrúnmìlà ní ànfààní láti se. Ire gbogbo tí èdá ń wa kiri owó èmí ní gbogbo re wa. Fun àpeere:-

A dia fun Òrúnmìlà

Níjó to ń lo r’emi omo Olódùmarè s’Obinrin

Ó ní àsé bemi ò ba bó

Owo ń be

Hin hin owo ni be

Àsà bemi o ba bo

Aya ń be

Hin hin aya ń be

Àsé bemi ò bá bó

Omo n be

Hin hin omo ń be

Ase bemi ò bá bò

Ire gbogbo ń be

Hin hin ire gbogbo n be …


Wande Abimbola Ìjìnlè ohùn enu ifá Pg 16 (Eji ogbè). Apa kinni

Odù náà je oken nínú àwon ìyàwó òrúnmìlà tí o ko orire ràn án. Alátìleyìn ni odù je fún Òrúnmìlà. O dìgbà tomo èkósé ifa ba to fojú ba odù ko to deni ara re. Èyí túmò si pé babaláwo tí kò ba fojú bodù kò tii dangajia.

Eni bá fojú bodù

Yoo si dawo

A fojú bodù a rire


OBÌNRIN GÉGÉ BI OLUBI

Àbùdá kejì yìí ní yóò tu tìfun tèdò ihà kejì tí ifá ko si àwon obinrin. Ifá ri àwon Obinrin gégé bi eni ibi, alásejù, òjòwú àti àjé. Ó fi ìhà yìí hàn tori pe a kìí dara ka ma kù sibi kan.

Ifá fi won wé aláigboràn ewúré tí wón máà ń se àtojúbò àwon ohùn tí ko kàn wón. Bi àpeere Yemòó fe mo ìdí agbára Óòsáála oko rè pèlú èdó tí ó fi ń pa eran ohun tójú tíle-túle alaigboran ń ri ní ojú re rí lojo yìí. Òrúnmìlà so fún àwon ìyàwó yòókù láti mase yojú wo òròmòdìmòdì obìnrin rè tuntun.

Ìyáálé pé àwon yòókù láti lo yojú wo ìyàwó tuntun yìí inú bí ìyàwó tuntu, o si jade. Ó sì fi won ré bayí ni Àjàkálè àrùn si wole to won. A ko le fí gbogbo ara da ìyaálé àti àwon ìyàwó yòókù lébi torí Òrúnmìlà ti ye kì ó fi ìyàwó tuntun han àwon to ba ní ilé sùgbón ó kò ko se èyí nípa ojú tí òrúnmìlà fí wo Obìnrin tí a le so pe Òrúnmìlà lo fí owó ara re da ilé ara rè ru. Eni ba wa wàhálà dandan ni ki ori i.

Ifá tun fí àwon obinrin hàn gégé bí òjòwú, ti won kìí fe ki oko won fe ìyàwó mìíràn le won àfi àwon nìkan. Fún àpeere:

Òkan soso péré lobìnrin

Dùn mo lówó oko

Bí won ba di méjì won a dòjòwú

Bí won ba di meta

Won a deta ń túlé

Bí won bad è merin

Won a dí iwò lo rín mi ni mo rin o

Bi won ba dí marun

Won a di lágbájá ni ó run oko

Wa tan lóhùn susuusu

Bì wón ba dí méfà

Won a dìkà

Bi wón ba de meje

Won a d’àjé

Bí wón ba di mejo

Wón a di ìyá alátàrí bàmbà…

Ìjìnlè Ohùn Enu Ifá Apá Kìínní pg 29-43 (Òyèkú meji) Wande Abimbola

Ohun tí o je ìjojú ní wípé Ifá gan-an mo pé ó sàn fún okùnrin láti fe ìyàwó kan. Èsè amomoda ni èyí ko ye ki Ifá maa fe ìyàwó lórí ara won.

Eke àti Òdàlè ni Ifá tún pe àwon obìnrin. Ohùn tí Ifa ń so níbí ni pe Obìnrin ko se fi inú hàn sùgbón ibeere tí a ba bi Ifá ni pe se okúnrin ni o se fi inú hàn. Bi o ti wa ni lìkì ni ó wa ni gbanja

Obinrin leke

Obinrin lodale

Keniyan se pele

Ki o ma finu han f’oobinrin (CL Adeoye pg 243 ese ifá kan nínú Obara meji)

Ifá te síwájú nìpa pipe àwon obìnrin ni dókodóko àti alágbèrè. Èro ifá ni pé àlè yiyan yìí kii je ki won tonu lopo igba pe eni to ba keré soko ni won maa ń ba dálè.

Àgbìgbòniwònràn, The unfaithful Ifá priest

You have been seeing bad things,

Worse things are yet to come;

Worse things the father of bad things

Ifa divination was performed for Agbigboniworan

Who was going to the house of Onkoromebi to perform divination

Onikoromebi, husband of an adulterous wife

It was because of the incessant adultery

Of his wife that oniworonebi

Performed divination

Igba ti o fìyà je obinrin naa tan

O gbe ju, agbala

O si de e lokun mólè

Ni àgbàlá ni onikoromebi fi ìyàwó re sI

Ti o fì lo bìfa léèrè

Àgbìgbò ní ki Onikoromebi o se sùúrù

O ní eni tí o torii re bi ifa léèré

Mbe loride nínú àgbàlá

Igba ti onikoromebi gbo

Oju ti i

Ko lee lo tu ìyàwó rè sílè mo

Ó ní ki Àgbìgbò o lo ba òun tu u sílè

Ìgbà tí Agbìgbo débè

Dípò ki o tu obìnrin náà sílè

fefe ni ń fe e….

(Ifa Divination Poetry pg 87-88)

Nígba tí ìyàwó onikoromebi náà yan babalawo ti won ni ko ba won wo aisan agbere lara re. Sùgbón ojo yìí ní ibi won wole nítorí bibe ní oníkòròmebi be àwon mejeeji. Babalawo tì won ni ko wo aya onikoromebi ko ni ètó lati se èyí. Bí wón ba pe obìnrin ni dokodoko. Obìnrin ko le da oko dó laì ri okunrin. Fi obìnrin é yálè yàlè alainisuru a ri eleyi nínú Sixteen great poems of Ifa Not long again. They sent for Òrúnmìlà in the abode of Olokun when Òrúnmìlà was going he did not take Òrò his wife along he promised to return on the seventeenth day. He gave sixteen òké measures of cowries to òrò. He also gave her clothes and plenty of food in the third month that Òrúmìlà had stayed away. For Example:

Òrò met Ońdàáró

They agreed to be Concubines

Ondaaro gave her five oke measures

Of cowries He cohabited with her,

And he became pregnant.


Òrò met onigoosun

After they had talked together

Onìgoosun gave her ten Oke measures

Of cowries

And cohabited with her

And again she became pregnant

Not long again òrò met a man named Olúùkóoló He gave har tiventy oke measures of cowries after they hed fun with each other òrò became pregnant again. All together the children of Òrò thus became six and they were all boys out of the six children three were children of Concubines.

Nínú esè Ifá yìí fi hàn wá wípé Owo l’obinrin mò gbogbo àwon meteeta to ba dálè yìí owó ní won fi hàn òrò.

Aritenimoo wi, a fi apadi fenfe bo tirè mólè ni Ifá ibeere ti a ba bi òrúnmìlà nip e se ko ba obinrin kankan ni àjosepò ni ìrìn àjò re. Ko si eni to mo iye omo ti o`hun na bi si àjò. The Sixteen Great Poems of Ifa pg 216-221 Wande Abimbola

Ifá rí obinrin han gégé bi àjé

Fun àpeere:

Béè ba gbolagbalagba epo òun ewùso

E lo lee ko fún ìyàmi Òsòròngà

Apa nimawaagun, Olokiki Orù

Ajedo-tútù-mo-bi

Obinrin kukuru regiregi

(The 16 Great Poems of Ifa pg 242 Wande Abimbola)


Àwon obìnrin náà ni Ifá tún fihàn bí aforesunu se. Won fore su Òrúnmìlà nílé ayé pé àwon o ni sòkalè ní ikùn re mó àfìgbà to ba rúbo.

Won ní kí ní ń je siso kale

Won ni a tun sòkalè mó

Òrúnmìlà ti mo Oko ni oko ikun to gbin èpà síbè. O mo pé ìhòhò ní àwon eleye wa ko to gbà láti se won ní àánú. Kìí se Òrúnmìlà nikan ní àwon eleye be. Òrúnmìlà tí gbàgbé pe bí ojo oore ba pé asiwèrè a gbàgbé àti pé ìwòn ní oore.

Aláwomó àti alakooba ní won gégé bi ìwà ti ìyá arúgbó tí a fi se àpeere nínú òyèkú méjì wù. Nígbà to fòrò isú lo enikan ti ko gba a je o fi owo epo sàmì sìi lára. Ebi kii se ebi eni to fi owó epo to o ni leke eni to rin ìrìn ìwàsà o di dandan kan fi èkùró lo o Fun àpeere:

Ó mú owo epo

Ó fi to mi léèkée mi òtún itororo itororo

Ó mú owo epo

Ó fi to mi leeke mi òsì itòròrò itòròrò

Ìjìnlè ohùn enú ifá pg 29-107-110 Òyèkú meji Wande Abimbola

Ifá tún je ka mo pé ìkà àti òfinràn ni won. Nínú méjì Yemoo ìyàwó orisà ńlá lo ji omi àwon eleye pon to so tun fo aso òdé re sínú odò náà


The witches asked, Did

She stab herself and Èlúlù

Replied she did not

Stab herself, the blood was

From her private part (The 16 Great poem ifá)

The witches therefore swallowed both the husband and the wife. Álásejù baba àseté tún ní ifá fe won ohun ti won se náà nìyí tí ó je ki nnkan bótí mo won lówó. Won kí àsejù bo òrò won. Fun àpeere :

Igbó etílé t’oun tegbin

Adapo owó toun tiyà

Iwo o ju mi

Emi o ju o

Lara ile eni fi ń fojú di ni (Oladipo Yemitan ati Olajide Ogundele Oju Osupa Apa keta)

Ifá je ka mo wípé Olódùmarè yan òrìsà merindinlogun ó fi òbìnrin kan si wípé ki wón maa lo silé aye láti maa lo rúbo fún àwon èmí airí. Nígbà tí won dé ilé ayé osun tí ó je obìnrin àárín won ní ó maa ń se ìpèsè fún àwon èmí airi yìí.

Ní gbobgo ìgbà tí won bat i n lo gbe ebo yìí lo fún àwon emí airi yìí osun kìí tèlé won, ti won ba ti de ibè gbogbo àwon òrìsà wònyí lo maa ń ko gbogbo ìpèsè yìí je, sùgbón won ko mo wípé Olódùmarè tí fun osun ni agbára láàrín won nígbà to yá gbogbo nnken kò gún régé mó won sa ògùn títí kò je mo. Bayi ní won se pínú láàrín ara wón láti rán òrìsà ńlá lo sodo Olódùmarè sùgbón òrìsà ńlá ko láti lo. Ní ifá bá ní kí wón ran ohùn lo sódò Olódùmarè nígbà tí Ifá de ibè lo ba so fún Olódùmarè wípé nnkan ko gún régé mò o. Olódùmarè ba ni osun ń ko o ni gbogbo nnkan te ba ti n se e fi t’obinrin si.

Bayí ní gbogbo àwon òrìsà yòókù bu lo si òdò osun láti béè sùgbón òsun ko gba èbè béè lo bèrè si ni mu gbogbo won bu leyo kookan láti orí Oosala, Òrúnmìlà Sungo, oya obalùfòn àti bebe lo ó ní nnkan tí won jo ràn àwon ń ko? lo ba so fún won wípé omo to wà ní ikùn ohùn tí ohun ba fi bí obinrin Olódùmarè yóò fí àwon elomíran dipo won. Sùgbón to ba je pe okunrin ní ohun fi bi o ni ohun yoo fi won silé wípé ohùn náà ti ni lara won niyèn ni osun ba fi oyin re bi okunrin láti ìgbà yìí tí won bat í ń lò sI igbó emí airi láti lo run won maa ń lo gbé omo òsun láti fi owó tirè náà sI gbogbo nnkan ti won ba ń se tan ba se tan won à dá pada fún ìyá rè.

Igba yìí lo ti so pé tó ba je okunrin ko ma je Akin osó. Ni ki a

Ka kúnlè

Kí Obìnrin

Òbìnrin lo bi wa

Ka to di ènìyàn …


Ifá je ka mò wípé alagbará ni àwon obìnrin Olodumare lo pin won ile agbara yìí. Gbogbo bi àwon òrìsà yòókù se ń ko ípèsè yìí je òsun mo si sùgbón ó se bi ènipe ohun ko mo nnkan to ń selè.

Alagbara ní won bí won se le lo agbara won lati fi se daradara ni won fi le se búburú. (Olóyè Babalola Fatoogun (Ifá Priest) Ilobu Osogbo.)

Ifá tún so ìtàn nipa àwon obìnrin ajo àti ìpàdé to maa ń se o fi hàn bo fe lo agbara àwíse lati fig be òrò kalè ni gbogbo ìgbà tí won ba ti fe se ìpàdé.

Ni òpòlopò ìgbà gbogbo agbara àwíse to ba so labe ge. Nitorí ó dúró gégé bi agbára ìtúsílè àti agbara Hayese.

Bo se dí ojo kan àwon òfá wa ònà láti ji agbara náà gbe won ko ri bi won se lo ba ìyàwó òrúnmìlà pìyí pe to ba juwe ibi ti agbara òhún wa fun àwon àwon o fun lówó.

Ìyàwó Òrúnmìlà gba owo, o si gbe agbára náà o lo bo mo inú eérú ojú àrò. Nígba tí Òrúnmìlà fe se ìpàdé a koko gbìyànjú làtí bi ifá léèrè lori bi ìpàdé yoo se ri ni won ban i ko lo bo sango ojú eérú tori ke nnkan ba le senu ire àti pe kí àsírí to farasin le ba hàn sáyé.

Ìgbà tí Òrúnmìlà ti gbe eéru ojú aaro lati bo Sango tan lo ba ri agbara rè tí òtá to ń pè ni ìyàwó bo mo inú eeru náà. Ìgbà tí òtá ri pé won ko ri Òrúnmìlà mú náà bá tún lo ba ìyàwó re láti tún ta ete mìíràn ìyàwó Òrúnmìlà pèlú àwon òtá náà ba gbìmò láti lo ju agbara re sínú odò.

Ìgbà ti ojó àjò ń pe bò Òrúnmìlà lo bi Ifa léèrè bí ojó àjo yoo se rí nítorí ó tí mo bi obinrin se jé. Sùgbón ebo to jade sí nip é ki o lo ni eja abori ńlá kan, obi àbàtà, àti iyàn ìlèkè ko fi bo eleda re. Lílà tí Òrúnmìlà la inú eja lo ba agbára rè nínú eja. Ó gbà pe obinrin ni òdàlè ni won. (Lati enu Dro Agbájé ti won gba lenu Babalawo)

Ìtàn kan ti Ifa so fì Obìnrin hàn gégé bi òdèlè, afenimadenu olubi ènìyàn. Ifá so ìtàn nípa Òrúnmìlà ENI TÍ MO FÒRÒ WÁ LÉNU WÒ.

Oloye Babalola Falogun Ifa Priest Ilobu Osogbo.