Ilu Ijebu-Ode
From Wikipedia
C.O. Onanuga
Ijebu-Ode
Ilu Ijebu-Ode
C.O. Onanuga (1981), ‘Ìlú Ìjèbú-Òde’, láti inú ‘Odún Òrìsà Agemo ní Agbègbè Ìjèbú-Òde.’, Àpilèko fún Oyè Bíeè, DALL. OAU, Ifè, Nigeria, ojú-ìwé 3-6
ITAN IJEBU-ODE
Orísìírísìí ni ìtàn tí à ń gbó nípa ìsèdá ìjèbú Òde. Sùgbón èyí tí ó wó pò jù nínú àwon ìtàn náà ni mo ménu bà yìí;
Aládùígbò ni Odùduwà àti Alárè jé ni apá ilè Lárúbáwá. Odùduwà ni a gbó pé ó kókó sí kúrò ní agbègbè náà wá sí Ilé-Ifè. Léhìn rè ni Alárè kúrò ní ilè Wàdáì; tí ó gba asálè Núbíà dé Ilé-Ifè, tí ó sì se “e-nlé-ń bèun o” fún Odùdùwà. Alárè fi omobìnrin rè kan Gbórowó, fún Odùduwà láti fi se aya. Léhìn èyí, ó gba ònà Ìseri dé Ìbesè, títí ó fi dúró ní Ìjèbú-Òde. Ajèbú àti Olóde jé lára àwon àtèlé Alárè. Fún isé ribiribi won fún ìlú ni a se so Ibùdó náà lórúko won - Ajèbú-Olóde. Àpèjá orúko yìí ni ó di Ìjèbú-Òde lónìí yìí.
Léhìn Alárè ni Lúwà (OLÙ-ÌWÀ) náà dé láti asálè Núbíà. Òun náà gba ònà Ilé-Ifè, ó sì yà kí Odùduwà. Lúwà àti Àlárè bí omokùnrin kòòkan. Osi ni omo Lúwà; Eginrin sì ni omo Alárè. Ní àsìkò yìí. Osìn tàbí Olójà ni à ń pe Olórí Ìjèbú-Òde.
Èdè àìyédè bé sílè láàárín Alárè àti Lúwà lórí, i eni tí yóò je olójà. Nígbà tí wón to Ìfá lo lórí òrò yìí, ó fí yé won pé eni tí yóò je olórí kòì tíì dè!.
Kò pé kò jìnnà, léhìn ikú Alárè àti Lúwà, ni àjèjì kan tí o múrá pàpà-rere wòlú. Ònà Ondó ni àjèji yíí gbà wo ìlú. Kò pé, ìròhìn ti tàn ká pé àjìji kán fé gbógun wòlú. Èyí ni ó mú Apèbí (Olóyè pàtàkì kan ní ibùdó yìí) lo báa bóyá ijà ni ó bá wá ní tòótó. Àjèjì yìí kò fèsì lo báa bóyá ijà ni ó bá wá ní tòótó. Àjèjì yìí kò fèsì ju pé “Ìjà dà?. láti fi hàn pé òun kò bá ogun wá. Àjèjì náà fi yé wón pé Ògbòrògánńdá-Ajogun ni orúko òun. Ó jé omo Gbórówó tí í se omobìnrin Alárè tí ó fún Odùduwà fé ní Ilé-Ifè, Ipasè àwon ebí ìyáa rè ni Ògbòrògánńdà tò wá, léhìn ikú bàbá rè. Títí di òní, àdúgbò tí Apèbí tí pàdé Ògbòrògánńdà ni à ń pè ní ÌJÀDÀ.
Àpàbí lo fi tó olóyè àgbà Jaginrìn tí ó rán an nísé pé owó èrò ni àjèjì náà mú wá. Nígbà tí Jaginrìn bi Apèbí ibi tí àjèjì náà wà, Apèbí dáhùn pé “Oba-ńníta” (Oba wà ní ìta) nítorí ipò Óba ni ó rí i pé ó ye eni pàtàkì bí i tí Ògbòrògbánnńdà-Ajogun. Láti ìgbà yìí ni a tí mo Ògbòrògánńdà ní Obańníta, tí àjápè rè di Obańta di òní. Agbègbè tí Oníseémù ti lé òsà lo tí a fún Ògbòrògánńdà láti máa gbé ni ó júwe pé” ó tóó ró”- (Ibí yìí) tó láti dúró sí) ni à ń pè ní Ìtóòró di òní. Àdúgbò yìí ni a se òwón kan sí ní ìrántí Obańta, nítorí a kò mo bí ó se kú. Inú igbó kan ni tòsí Orù-Àwà ni a gbó pé ó rá sí.
Ògbórògbánńdá Ajogun (Obańta) gbé Winniadé, omo Osi níyàwó. Ósi yìí, bí a ti mò sáájú jé omo Lúwà. Obáńta sì jé omo-omo Alárè. Wón bí omokùnrin kan tí ó ń je Monigbùwà. Síbè aáwó tí ó wà láàárín Lúwà àti Alárè nípa óyè jíje kò í tán láàárín àwón ebí méjèèjì.
Láti fi òpin sí aáwò yìí, àwon ará ìlú ní kí Monigbùwà, omo Obańta, jáde rè ti se ní ojó kìíní. ‘Monigbùwà gbà láti se béè. Ó lo sí ìletò kan tí a mò sí Òdo, láti ibè ní ó sì ti padà wo ìlú pèlú ìfon àti orin. Ojó yìí ni a gbé adé fún Monígbùwà. Oùn ni ó jé eni àkókó ti ó je oyè Awùjalè - ‘A-mu-ìjà-ilè’-èyí ni eni tí ó parí ìjá tí ó bá nílè. Àpápè oyè yìí ni ó di Awùjalè dòní yìí. Títí di òní yìí ni enikéni tí a bá yàn gégé bí oba tuntun gbódò jáde ní ìlú lo sí Òdo, kí ó sì wo ìlú padà gégé bí i Monigbùwà àti Obańta kí ó tó ó gbadé.
Lára àwon olóyè pàtàkì-pàtàkì ní Ìjèbú-Òde ni Olísà Egbò, Àgbòn, Kakanfò, Jaginrìn àti Lápòekùn, tí wón jé óyè ìdílé. Àwon oyè bí i Ògbéni Ojà kìí se oyè ìdílé. Àwùjalè kokànléláàádóta ni a gbó pé ó wà lórí oyè báyìí.
Àwon Ìjèbú féràn láti máa je kókò àti òjòjò. Wón tún féràn lati máa fi ògìrì sí obè àti oúnje won mìíràn bíi ikókoré láti fún un ní adùn àjepónmulá.
ÈSIN Elésìn ìbílè ni àwon ènìyàn Ijèbú Òde ní ìgbà láíláí. Wón máa ń bo orísìírisìí òrìsà tí a ń bo ní gbogbo ilè Yorùbá bí i Ògún, Ifá, Èsù àti béè béè lo. Àwon òrìsà ìbílè bíi Agemo, Òrò, àti Obìnrin-Òjòwú wà pèlú.
Lóde oní àwon èsìn ìbílè wònyí kò ranlè bíi ti àtijó, síbè a sì ń bo wón lójú méjèèjì. Èsìn Mùsùlùnì ni òpò àwon ará Ìjèbú-Òde ń se báyìí. Mosálásí kan wà ní àdúgbò Òyìngbò tí ó jé òkan nínú mósálásí tí ó tóbi jù ni apá ìwó oòrùn Afríka.
Àwon elésìn àtèlé Krístì Lórísìírísìí kò gbéhìn. Àwon náà pò ní iba tiwon. Àwon ìjo Àgùdà tilè fi Ìjèbú Òde se ibùjúkóó fún dáyósíìsì ti ekùn Ìjèbú.
[edit] ADUGBO
1. Àdúgbò: Itaolówájodá
Ìtùmò: Àdúgbò yìí ni àwon ìjòyè Oba ìlú yìí tí a ń pè ni olówá tè dí, ti won si ń se ìjoba lórí àwon ènìyàn tó wà ládùgbó yìí
2. Àdúgbò: Olíwòro Ìtùmò: Àdúgbò yìí ni ojúbo òrìsà alá wà tétètélè, Àwon àwòrò òrìsà yìí ni ó te àdúgbò yìí dó.
3. Àdúgbò: Ìdóbì Ìtùmò: Igi obì púpò ni àwon tó te àdúgbò yìí bá nígbà ti wón fé te ìbè dó.
4. Àdúgbò: Ìtaòsù Ìtùmò: Àdúgbò yìí ni ojúbo òrìsà òsù wa. ni tori pe ibí yìí ni wón ti ń bo òrìsà yìí ni wón se ń pe e ni ìta òsù.
5. Àdúgbò: Imèpè Ìtùmò: Igi òpe púpò ni àwon tó te àdúgbò yìí ban i ibi yìí nígbà tí wón fé te ibè dó
6. Àdúgbò: Ayegun Ìtùmò: Àdúgbò yìí ni òkan lára àwon akoni ode to máa ń ye ojó ogun ti awon olóde yòókù bá ti dá síwájú tè dó ìdí niyìí tí won fi ń pe àdúgbò yìí ni Ayegun.
7. Àdúgbò: Ìtalápò Ìtùmò: Awon ounje orisirisi tí a dì sínú àpò bii àgbàdo, ìyo, ni àwon ara àgbègbè máà ń gbé wá si àdúgbò yìí wá lati tà kí ó tó di àdúgbò. Wón si máà ń na ojà ni àdúgbò yìí títí di òní yìí .
8. Àdúgbò: Ìsasà Ìtùmò: Isé ìkokò mímo ni isé àwon to té àdúgbò yìí dó. Díè lára àwon omo omo won si ń se ìsé yìí
9. Àdúgbò: Ìta Òsùgbó Ìtùmò: Àdúgbò yìí ni àwon Olósùgbó ti máà ń se ìpàdé. Níbè ni ilé ìpàdé wón wa, kí ó tó di pé won te ibè dó.
10. Àdúgbò: Ìsesí Ìtùmò: Ibí yìí ni ójúbo osi esi wà télètélè kí o to di pé won te ibè do tí o si dí àdúgbò ojúbo osi yìí si wa níbè títí dònìí.
11. Àdúgbò: Ìta Opó Ìtùmò: Àwon Opó ni won máà ń na ojà yìí ni alaalé. Òríta ti wón ń náà yìí ni o di adúgbò, ti wón si ń pe ni ìtà opó. Wón si máà ń ná ojà alé ni àdúgbò yìí títí dònìí
12. Àdúgbò: Molípáà Ìtùmò: Okunrin kan tó mú opà dání ló te apá ibí yìí dó. Ìtàn so fún wa pé àpá ase Oba ìlú ibòmíìràn ló mu dàni nígbà tí o ń bo, àwon kan tilè so pé Àremo oba ìlú náà ni. Nígbà tí o, fé te àdúgbò náà do ó mú òpá yìí dá ni, Ìdí niyìí tó fi je pé won ń je oba ni àdúgbò náà títí di òní yìí
13. Àdúgbò: Ìtóòrò Ìtùmò: Ìtàn so fún wa pé omi nigbogbo àdúgbò yìí teletélè kí ó to dí pe wón te ibè do. Okunrin akoni ti a ń pè ni òró ni o pé ofò tí ó sì le omi náà lo. Ìdí nìyìí ti a fi ń pé àdúgbò náà ni Ìtóòró.
14. Àdúgbò: Olóde Ìtùmò: Ibí yìí ni òkan lára àwon akoni tó te ìlú yii dó kokó dúró si kó tó dip é ó wo àárin ìlú lo. Nígbà ti ijà dé láàrin òun àti àwon tí wón fo wo ìlú yìí, o bínú pàdà si ibi yìí o si wolè. Ìdí niyìí tí wón fi ń pe àdúgbò naa ni Olóde. Oórì okùnrin yìí si wà níbè títí dòníì.
15. Àdúgbò: Odò Èsà Ìtùmò: Eégún kan ti won ń pè ni obrinrin ojòwú ní o te ibí yìí dó. Èégún Odoodún ni eégún máà ń jáde ni àdúgbò yìí títí donii. Ìdí igi ìrókò ni won fi se ojúbo eégún yìí Igi ìrókò yii wà níbè títí dónì yìí.
16. Àdúgbò: Ìdépo Ìtùmò: Isé epo ni àwon to te àdúgbò yìí yàn láàyò léyìn tí wón ti dó síbè. Bí o tilè jé pé won kò se ise epó níbè mó, won si ń ná ojà epo níbè titi dò níí.
17. Àdúgbò: Fìdípòtè Ìtùmò: Lára àwon ìjòyè oba Gbélébùwà àkókó tí won kò fara mo on pé kí wón pa Oba náà ni won wa te àdúgbò yìí dó léyìn ti wón kúrò ni ààfún.
18. Àdúgbò: Apèbi Ìtùmò: Oríta yìí ni àwon ìjoyè Oba Gbétebùwá àkókó péjo sí láti bi ara won ohun ti o ye kí àwon se fún oba náà.
19. Àdúgbò: Ìdéwòn Ìtùmò: Ìtàn so gún wa pé nígbà tí wín fe te ibí yìí dó, wón bá òrìsà kan níbè tó dé adé sórí tó sì fi èwòn onírin se ileke owó àti tí esè. Ìdí ni yìí ti à fi máà ń yan Oba láti ìdílé enití ó te àdúgbò náà dó. Ìdílè yìí náà tílè ni ààfún tí a ń pè ni ààfin Òba ìdéwon.
20. Àdúgbò: Ìta Àfín Ìtùmò: Ìtàn so fún wa pé bí ó tilè jé pé èrúktí o té àdúgbò yìí do kii se àfín, sùgbón gbogbo àwon omo tí won bi láti ìdílè enití o te àdúgbò náà do je àfín. Nígbà ti won lo bi ifá wo, Ifá ni ki won máà bo Obàtálá ni ìdílé náà, láti ìgbà náà lo ni won ti ń bo Obàtálá ni ìdílè yìí. Ti o bad i àsìkò odún òrìsà yìí, àríyá ni fún gbogbo àwon omo àdúgbò yìí àti fún ìlú pàápàá. (see Yoruba Place Names)