Ewi Ayaba
From Wikipedia
Ewi Ayaba
M.O. Oyewale
Oyo
Osun
Oyewale
M. O. Oyewale, ‘Àgbéyèwò Ewì Ayaba láàrin Àwon Òyó-Òsun’., Àpilèko fún Oyè Eémeè, DALL, OAU, Ifè, Nigeria.
ÀSAMÒ Isé yìí se àgbéyèwò ewì ayaba láàrin àwon Òyó-Òsun. Ó sì jé kí á mò nípa àbùdá ewì ayaba, ìsowólò-èdè ewì ayaba, ogbón ìsèré ewì ayaba àti ìwílò rè láwùjo. Ogbón ìwádìí tí a yàn láàyò nínú isé yìí ni gbígba ohùn ewì ayaba sínú fónrán. Àwon ìlú márùn-ún tí agba ohùn ewì ayaba won sínú fónrán ni Òsogbo, Ede, Ìláwó-Èjìgbò, Ìwó àti Ìkòyí. Léyìn náà, a se àdàko ewì wònyìí, a sì se àtúpalè rè. Síbè, a fi òrò wá àwon oba ìlú tí a ménubà yìí lénu wò. A tún ka àwon ìwé tó bá isé yìí mu. Tíórí ìbára-eni-gbépò láwùjo ni a yan láàyò láti fi se àtúpalè àkòónú àti ìsowólò-èdè inú ewì ayaba yìí. Ìwádìí lórí isé yìí fi hàn pé ewì ayaba jé èyà lítírésò alohùn Yorùbá tó jé ti àwon obìnrin; ní pàtàkì jùlo ìyàwo oba olorì oba tàbí ayaba. A jé kí ó di mímò nínú isé yìí pé àwon ayaba a máa ké ewì won yìí láàfin tàbí nínú ayeye tó kan oba ìlú dáradára. A so nínú isé yìí pé ìsòrí ayaba méjì tí a mò sí ayaba àgbà àti ayaba kéékèèké ló ń lówó nínú ewì yìí. Ní ìkádìí, isé yìí sàlàyé pé orin àti ìsàré ni ewì ayaba Òyó-Òsun. Ìwádìí lórí isé yìí sì jé kí á mò pé ewì ayaba yìí gbajúgbajà nínú síse ìjíyìn nípa ayaba, oba àti àwon ìsèse inú àwùjo kòòkan. Síbè ewì ayaba yìí tún je mó ìwúre fún oba àti ebi oba
Alámòójútó: Òmòwé J.B. Agbájé
Ojú Ewé: 228