Iwe Akonilede Ijinle Yoruba

From Wikipedia

Akonilede ijinle Yoruba

Adebisi Aromolaran Oyebamiji Mustapha (1975), Akómolédè Ìjìnlè Yorùbá Lagos Macmillan Nigeria Publishers Ltd. Ojú-ìwé = 175.

ÒRÒ ÌSAÁJÚ

Ìwé yìí ni èketa nínú òwó ìwé Akómolédè Ìjìnlè Yorùbá, òun pàápàá ni ó sì parí òwó náà. Ìwé èyí se pataki, pàápàá jù lo fún àwon akékò tí wón ń dá’ná mó’rí ní odún àbáyorí èkó won fún ìdánwò WASC.GCE ati ti àwon olùkó onípò gíga. Béè gégé, ìpìlè tí ó l’ágbára ni ìwé yìí fi lé ‘lè fún àwon tí ń gbáradì láti kó ìjìnlè èkó èdè yorùbá gege bi ìlànà ti òde-òní ní ilé-eko gíga jù lo fún àwon olùkóni ati ilé-èkó gíga ti Polytechnic.

A ní ànfààní lati se ìmúlò nínú ìwé yìí, orisirisI àbá tí awon ìgbìmò tèékótó tí Ìjoba Àpapò ní Eko yàn lati rí sí báwo ni a se nílati maa ko àwon èdè mélò kan l’órílèdè wa sílè. Ìjoba ti gba àwon àbá ati ìlànà tí ìgbàmò náa se lórí bí a se niláti máa ko èdè yorùbá sílè, ìjoba sì ti fi àse sí i pé ìlànà wonyi nilati di kàn-ń-pá fún liko lati odún 1977. A ménuba àbájáde isé ìgbìmò yii ní èkúnréré ní Èkó kinni nínú ìwé yìí.