Lawuyi Ogunniran

From Wikipedia

S.T. Adelabu

Lawuyi Ogunniran

Iwi

Eegun Alare

S.T. Adalabu, (1989), ‘Ìtàn Ìgbésí Ayé Láwuyì Ògúnníran’, nínú ‘Ìlò Èsà tàbí Iwì nínú Eégún Aláré.’, Àpilèko fún Oyè Bíeè, DALL, OAU, Ife. pp.24-25.

ÌTÀN ÌGBÉSÍ AYÉ ÒNKÒWÉ A bí Láwuyì Ògúníran ní ojó Etì ojó kìíní osù Bélú (Novermber), odún 1935 ní abílé Akínkúnmi ní ekùn Ìròkò ní Ìjoba ìbílè Àríwá Akínyelé ní ìlú Ìbàdàn ní Ìpínlè Òyó. Orúko bàbá rè ni Samuel Àmòó Ògúnníran nígbà tí tí ìyá rè tó ti di olóògbé jé Julianah Oyáróhunké Àlàké Ògúnníran. Àgbè hán-ún ni bàbá Láwuyì nígbà tí ìyé rè jé onísòwò pépèpé. Inú èsìn kírítenì ni a bí Láwuyì sí. Èsìn kírítenì ni àwon ara ilé bàbá rè ń se nígbà tí àwon ará ilé ìyá rè jé elésìn kírítenì àti elésìn mùsùlùmí. Bàbá Láwuyì kóríra èsìn abòrìsà púpò. Láwuyì Ògúnníran kò tètè bèrè ilé-ìwé nítorí àsà owó tétí kò tétí tí àwon olùkó ìgbàanì máa ń wí. Nígbà tí Láwuyì pé omo odún mésàn-án ló bèrè ilé-ìwé alákòóbèrè ní ilé-èkó ìjo Elétò ní ìlú Fìdítì lékùn Òyó. Nígbà tí ó jáde nílé ìwé náà ó sisé fún ìgbà díè kí ó tó tún tè síwájú nínú èkó re nítorí pé owó já a ní tànmó-òn. Lásìkò yìí ni àmódi kolu òbí rè. Léyìn èyí Láwuyì Ògúníran kàwé abélé láti gbàwé èrí oníwèé méwàá (General Certification of Education). Láwuyì sisé ní ilé isé orísìírísìí kódà ó se akòwé kékeré lábé ilé-isé agbejórò (Lawyers Chambers). Ní osù Agemo ní odún 1962, Láwuyì dara pò mó àwon òsìsé ilé-ìtèwé “People’s Star Press Limited”. Ìgbà tí àwon ògá rè rí í pé Láwuyì Ògúnníran gbó èdè Yorùbá dáadáa wón sí i nípò lo sílé ìtèwé “Ìmólè Òwúrò” tí ó jé èka ìwé ìròhìn tí won ń tè jáde. Láwuyì ni ó ń mójútó àwon ìròhìn tó bá wolé, léhìn èyí Láwuyì di igbákejì olótùú ìròhìn kí ó tó tún wá di olótùú ìwé ìròhìn náà. Láwuyì ní ìwé èrí dípúlómà nínú isé akóròyìnjo (journalism). Lónìí, Láwuyì Ògúnníran ni Olótùú Òkin Olójà ti ilé-isé Túbòsún Oládàpò ń gbé jáde. Isé mìíràn tí Láwuyì tún ń se léyìn isé ìròhìn ni isé ònkòwé àti àgbè alároje. Láwuyì Ògúnníran ni ìyàwó ó sì ti bi àwon omo okùnrin àti obìnrin.

L.O. Adewole (2006), 'Eegun Alare', DALL, OAU, Ife, Nigeria.

[edit] Eégún Aláré

  1. Òjè Lárìnnàká àti Dásofúnjó

Òré tímótímó ni Òjè Lárìnnàká àti Dásofúnjó ní Òkèehò. Òjè Lárìnnàká lo pidán ní ìlú kan tí idán pípa ti tà. Ìdíwó ilé kò jé kí Dásofúnjó lo ní tirè. Aya Òjè Lárìnnàká tí ó ń jé Iyadunni ti lóyún ní àkókò yìí. Òjè Lárìnnàká dágbére fún àwon ebí rè àti fún Dásofúnjó. Dásofúnjó fún un ní ìwon nnkan tí ó ní tí ó lè fi se agbára kún èyí tí ó ní tí ó lè fi se agbára kún èyí tí òun náà ní. Ó dágbére fún ìyàwó rè ó sì sèlérí láti wá mú un kí ó tó bímo. Àwon omo èyìn rè gbé òkètè tí ohun èlò ìpidán wà nínú rè rù wón sì mú ònà ìrìnàjò won pòn. Ìyádùnní sìn wón sónà ó sì fi èsà ki oko rè. Èsà ni ewì tàbí iwì eégún. Nínú èsà tí Iyadunni fi ki oko rè ni a ti rí i pé Ìrèmògún, ará Ìlágbéde, eni tí ó máa ń lu irin tí ó ń tún un ún se ni Òjè Lárìnnàká. Ìyádùnní be oko rè nínú èsà yìí pé kí ó má gbàgbé òun nítorí pé lílo tí ó ń lo, kò dá ìgbà kankan tí òun yóò padà. Òjè Lárìnnàká náà fi èsà dá aya rè lóhùn pé ki òun náà má se gbàgbé òun. Dásofúnjó se ìtójú ìyàwó òré rè dáadáa. Títí tí ìyàwó fi bímo Òjè Lárìnnàká kò dé. Dásofúnjó àti àwon ebí ni ó so omo náà ní Ojélàdé fún esèntáyé omo yìí tí wón lo yè wò lódò babalawó odù òsá méjì ni ó go lójú ópón. Ese Ifá yìí so pé isé baba re ni omo yìí náà yóò se. Ifá ní ‘…Awo ààsàì goróyè’. Wón ní kí won rúbo. Awon ohun ebo sì ni eyelé mérin, àgbébò adìye mérin, obì gidi mérin àti òpá aso mérin. Wón rú ebo yìí. Léyìn odún méwàá tí ó ti bímo, Ìyádùnnì pinnu láti wá oko rè lo nítorí pé lójú rè, oko eni kú sàn ju oko eni nù lo àti pé wo ìsò dè mí kò lè dà bí onísò, ojú méwàá kò sì lè jo ojú eni. Ìyádùnní ní, lóòótó, Dásofúnjó tójú àwon síbè, àwon nílò láti wá Òjè Lárìnnàká lo. Léyìn odún kan ti Ìyádùnní àti omo rè ti kúrò ní ilé, wón pinnu láti dúró ní ìlú kan láti sisé díè nítorí pé owó ti ń tán lówó won. Wón ń gba àárù láti fi lè rí owó díè. Léyìn ìgbà tí wón ti se eléyìí fún ìgbà díè ni wón bá pinnu láti padà sílé nítorí pé bí iwájú kò bá seé lo, èyìn á á seé padà sí. Nígbà tí wón dé ilé, wón fi Òjélàdé sí òdò Dásofúnjó láti máa kó idán pípa. Dásofúnjó kó o ní isé yìí fún odún méwàá, ó sì yege. Léyìn ìgbà tí Òjélàdé ti kó isé tí ó yege tán ni ó pinnu láti wá ire tirè lo sí ìlú mìíràn nítorí pé “Erin kìí fon kí omo rè fon” Kí Òjélàdé tó lo, Dásofúnjó fún un ní omo rè, Ànséètù láti fi saya. Ní ojó kejì léyìn ìgbéyàwó ni Òjélàdé, ìyàwó rè àti àwon omo isé rè lo sí àjò. Nígbà tí wón dé ìlú kan, wón pinnu láti fi ibè se ibùdó kí wón sì máa ti ibè lo máa saré ní ìlú mìíràn. Tí Òjélàdé bá ń lo seré kì í mú ìyàwó rè dání nítorí pé kì í lo àlosùn. Nígbà tí ó se, Baálè ken pè é pé kí ó wá seré fún òun. Nígbà tí Òjélàdé ń lo jé Baálè yìí, ó mú ìyàwó rè dání. Ìrìn ojó méta ni ìlú yìí. Nígbà tí wón dé ibè, wón fi wón wò sí ilé Balógun ìlú yìí. Kí wón tó seré Òjélàdé àti ìyàwó rè jo lo kí àgbà eégún aláré kan ní ìlú yìí. Wón fún un ní èbùn. Òjélàdé so fún bàbá yìí pé òun wá saré ní ìlú náà ni. Bàbá yìí sì kí won dáadáa sùgbón gbàrà tí ó ti rí ìyàwó Òjélàdé ni ó tin í ifé rè gidi gan-an nítorí pé obìnrin tóí ó léwà púpò ni. Bàbá yìí be ìyàwó Òjélàdé pé kí ó fé òun sùgbón ìyàwó Òjélàdé kò jálè. Nígbà tí Ànséètù so fún oko rè nípa òrò yìí, oko rè lo ba bàbá yìí bàbá yìí sì so pé òun ti gbó. Ó ní òun kò mò pé ìyàwó rè ni. Kí ó tó di pé Òjélàdé be bàbá yìí kí ó tó gbà gan-an, bàbá yìí ti lérí pé òun lè pa Òjélàdé tí ìyàwó rè bá kò láti fé òun. Sùgbón gégé bí a se so sáájú, Òjélàdé be bàbá yìi, ó sì so pé òun gbà Òjélàdé. Ó se wón dá ojó eré. Ní ojó eré, wó kerèé ó ta òkìtì, ó di Òyìnbó, ó di olópàá ó sì di ekùn. Nígbà tí ó wó kerèé, ìyen nip é nígbà tí á di erè (ìyen òjòlá) ni Òjélàdé kò bá lè yí padà di ènìyàn mó. Oníbàtá ń so pé kí won la òjòlá kí won gbé omo ènìyàn jáde. Bí wón ti ń la òjòlá ni Òjélàdé ń so pé ara òun ni wón ń gé. Òjélàdé bèrè síí pèsà. Ó pè é dé ibi tí ó ti so pé “Lárínnàká, oko Iyadunni” ni bàbá òun. Bí ó ti pèsà dé ibí yìí ni bàbá kan bá jáde tí ó so pé omo òun ni Òjélàdé àti pé òun ti fi owó ara òun se ara òun. Ó ní òun ni òun se Òjélàdé nítorí pé òun fé gba ìyàwó rè. Ó tún se àlàyé síwájú sí i pé omo òun ni Òjélàdé àti pé ìyá rè ní oyún rè sínú ni òun kúrò ní ilé. Ó ní àdámò ni ó dà fún òun. Báyìí ni àwon èrò ìwòran se so ó di “Bàbá Àbámò”. Wón ní kí bàbá yìí lo mú èrò wá. Ó lo mú ìdó kan tí ìkóóde wà lénu rè wá ó sì gbé sìgìdì kan tí ó ń rin sin-in fún epo dání. Ó bèèrè fún èjè ewúré, Baálè wá a fún un. Ó ní kí won, ta kerèé yípo òjòlá náà, wón sì se béè. Ó dúró sí èyìn kerèé náà, ó fi èjè ewúré yí àdó oníkóóde náà. Ó mú àdó sí owó òtún, ó gbé sìgìdì sí owó òsì, ó sì bèrè síí pe ofò. Léyìn ofò yìí, Òjélàdé jáde kúrò nínú kerèé. Òjé Lárìnnàká fi èsà dúpé lówó Baálè wón sì korin pé, “E jé ká relé, ilé là ń lo; Àjò kan kò gbeni gbeni, kó dàbí ilé”. Wón padà sí ìlú won.


  1. Òjélàdé Omo Ojè Lárìnnàká

Léyìn ìgbà tí wón ti padà dé ilú tan ni Òjélàdé bá tún múra àtilo sí àjò mìíràn. Òjé Lárìnnàká ti dàgbà nígbà náà. Ó fi òpòlopò agbára rè han omo rè. Kò pé léyìn èyí tí ó fi kú. Omo rè se òkú rè fún osù méta Léyìn ìsìnkú yìí ni Òjélàdé wá múra ìrìnàjò rè. Nígbà tí ó dé ìlú kan tí ó ti fé saré, ó lo láti gbàyè lówó Baálè, oníyen sì fún un. Ní ojó eré, gbogbo ènìyàn pé jo láti wòran. Ní ojó yìí, Òjélàdé kò júbà kí ó tó bèrè eré gégé bí ó se máa ń se télè. Dípò tí Òjélàdé ìbá fi kókó júbà kí ó tó bèrè eré, ofò ni ó ń pè pé, “A kìí ráféfé mú…” A kò mò bóyá páàgùn ni ó ń dà á láàmu nítorí pé “ó gbékè lé agbára tí bàbá rè fún un”. Nínú èsà rè, ó ki Baálè ní “Ìkòyí omo erù Ofà” Nígbà tí Òjélàdé ki Baálè dé ibi tí ó ti so pé, “Èsó Ìkòyí, dá mi lóhùn ìwo ni ng ké sí” ni Baálè ni Baálè àti àwon ìyòyè bá fún Òjélàdé ní òpòlopò owó Baálè sì tún fún un ní Omobìnrin kan kí ó fi se aya. Òjélàdé fi èsà dúpé. Léyìn èyí ni ó bèrè síí pidán. Ibi tí Òjélàdé ti ń pidán ni àwon àgbà òjè tip é kí ló dé tí kò júbà kí ó tó bèrè eré. Orin àrífín ni Òjélàdé fi dá wo lóhùn pé, ‘Ìkòkò tó fojú deyìn, a fó…”. Àwon àgbà òjè yìí wá dan án. Ó di ònì, kò lè yí padà di ènìyàn mó. Nígbà tí Òjélàdé ti rí i pé òun kò lè yí padà di ènìyàn mó ni ó bá fi èsà so fún omo èyìn rè kan tí orúko rè ń jé Òjékúnlé pé kí ó lo bá òun mú èrò kan wá. Ó ní ‘O ó bá mi délé babami. Àdó kan ń be lájà a-mi-ló-ló-ló’. Àdó yìí ni Òjélàdé fi èsà so fún Òjékúnlé pé kí ó bá òun mú wá. Bí Òjékúnlé ti gbó ni ó ti mú ònà pòn láti lo mú àdó náà wa. Kí ó tó padà dé, òjó ti sú ó sì ti rò lé ònì lórí. Bí òjò yìí se rò lé e lórí ni ó bá wó wo inú omi lo. Etí omi yìí ni ó wà tí obìnrin kan wá sí etí odò yìí láti da eèrí nù. Bí ònì ti rí obìnrin yìí ni ó pe èsà sí i. Èrù ba obìnrin yìí bí ó se rí ònì tí ó ń pé èsà ó sì fi ìbèrùbojo da eèrí orí rè nù. Bí eèrí ti ó dànù yìí se kan ònì yìí lórí ni ó bá yí padà tí ó di ènìyàn, ìyen ni pé ó yí padà ó di Òjélàdé.


Òjélàdé wá tèlé obìnrin yìí lo sí ilé. Nígbà tí ó dé dé obìnrin yìí, ó se àlàye gbogbo ohun tí ó selè fún òun àti oko rè. Òko yìí ni ó sì fún un ní aso tí ó wò lo sí ilé. Ó tilè dé ilé sáájú àwon omo èyìn rè.


  1. Òjélàdé di Baálè Arèkú-Eégún

Èdìdì tí a mú di ìrókò olúwéré, ara ló fi san Báyìí ni ó rí fún Òjélàdé. Lékèé gbogbo ohun tí ó selè sí i, ń se ni òkìkí rè ń kàn sí i. Ó se, òkìkí rè kàn dé òdò Aláàfin. Aláàfin wá pè é pé kí ó wá fi iga gbága pèlú Dúdúyemí kí won fi lè yan eni tí yóò je ‘Baálè. Arèkú Eégún’. Ìyàwó rè kékeré tí Baálè fi ta á lóre bè é pé kí ó má lo sí ibi ìdíje yìí, kò gbà. Ó ní ijó ‘Ijó eégún kì í hun bàtá, àborúboyè kì í hun omo Awó. Ó ní isé bàbá òhun kò lè hun òun. Ìyàwó yìí bè é títí, ó fi orí so ó láyà, ó sì dákú. Nígbà tí ìyàwó yìí jí, Òjélàdé fi lókàn balè pé, ‘Odíderé kì í kú sóko ìwáje, béè ni omo inú odi kì í kú séyìn odì’. Nígbà tí òrò ti rí báyìí ni Ànséétu, ìyen ìyàwó tí ó dákú tí ó sì jí yìí bá so pé òun yóò bá won lo, Òjélàdé sì gbà fún un láti bá àwon lo sí ibi ìdíje náà. Èsà pípè, àti ijó nìkan ni wón fé fi se ìdíje. Òjélàdé kò jé kí iná èsìsì jó òun léèméjì, ìbà, ni ó kókó jú lójú agbo. Léyìn ti ó júbà tán, Dúdúyemí náà júbà. Léyìn èyí ni Òjélàdé wá fi èsà so àwon itú tí ó ti pa. Dúdúyemí náà fi èsà so itú tí òun náà ti pa. Ní ìparí èsà Dúdúyemí ni ó tip e Òjélàdé níjà pé kí ó fi èsà kí àwon Ológbùró. Òjélàdé kì wón. Ó so gbogbo ohun tí wón ń se àti èyí tí won kì í se. Ní ìparí, ó ní kí Dúdúyemí èsà sàlàyé eni tí ó kókó gbóyín Ògburò lo sódò tó pòsé. Dúdúyemí so pé ìyàwó Ológburò nì. Ó ní òun ni oyún inú rè jáde tí ó sì gbé rù ú ní odò. Nígbà tí obìnrin yìí dé ilé, ó so fún oko rè. Wón dífá, Ifá so pé okùnrin ni omo náà yóò jé àti pé ogun ni yóò máa jà. wón bí mo tán omo kò yéé sunkún nì wón bá gbé e jù sí, inú igbó. Nígbà tí won yóò fi padà dé ibè ní ojó kerìndínlógún, won kò bá omo mó. Omo ti bójú ogun lo. Bí Dúdúyemí ti dáhùn báyìí tán ni òun náà bèèrè ìbéèrè lówó Òjélàdé lórí Ológbùró ken náà. Òjélàdé sì dáhùn pé, ‘Oníkòyi lomo tí wón gbé jù sí gbàgede rè. Òun lÈsó Ìkòyí, omo erù Ofà’. Ogun tí omo bá lo, nígbà tí ó di odún kerìnlélógún tó tì bógun lo ni ó ránsé wálé pé kí won ó bá òun kí bàbá òun, ‘Omo a jáwé gbogbo pè é lóògùn’. Oríkì rè yí fi hàn pé onísèègùn ni. Dúdúyemí ní òótó ni Òjélàdé ń so. Òjélàdé náà wá ni kí Dúdúyemí bá òun dé, ‘Ilé Èdè Òdí Mode Ìresà’. Dúdúyemí náà fi èsà dá a lóhùn ó sì fí yé nip é isé epp síse ni isé won. Bí Dúdúyemí ti parí ni ó so fun Òjélàdé náà pé kí ó so ohun tí ó jé èèwò nílé ará Ìresà. Òjélàdé fi èsà se àlàyé ohun méta tí ó jé èèwò won. Won kì í fi kèké retí. Won kì í fi kèké ròfó. Won kì í fi agbada dínran je. Dúdúyemí náà tún gbà á lénu Òjélàdé léyìn ìgbà tí ó ti so pé òótó ni Òjálàdé ń so. Ó ní, Ìrù esin lòòsà nílé ara Ìresà’béè ni, ‘Ikin níí gbe ni’. Bí Dúdúyemí ti so eléyìí tán ní Òjélàdé wá bi í pé ta ló kókó rèkú eégún, ìyen ni pé tan i eégún àkókó ní ilé ayé. Dúdúyemí dáhùn pé Ológbojò ni, ìyen. ‘Èsà Ògbín, ará Ògbojò’. Duduyemí náà wá bi í pé ta ni ó ni eégún gan-an. Òjélàdé dáhùn pé Àrè Òjé Olójowòn ni ó ni ín kí Èsà Ògbín Ológbojò tó bá agbé e. Léyìn èyí ni Dúdúyemí wá ki èsà tí ó sì sàlàyé bí wón se ni kí àwon eégún lo ponmi wá tí àwon àgbààgbà méje òde Ògbín-ilé yóò mu lé kóókò tí wón sun je lóko lásìkò tí ìyàn mú. Eégún méfà ni ó kò láti lo pé tí àwon bá lo tán, won yóò gba àgó lówó àwon. Èkéje tí ó lo, òhún tí ó rí òkú eégún tí ó fó agbè mólè ni eégún tó jí. Léyìn tí Òjélàdé ti so pé Dúdúyemí yege tán ni Dúdúyemí wá bèèrè lówó re pé ibo ni Yorùbá ti sè. Òjélàdé sì dáhùn pé Ifè ni. Léyìn ìgbà tí Òjélàdé ti dáké tán tí àwon ènìyàn sì ti pàtéwó fún un tán ni obá bá pa á láse pé kí wón pa ìtàn síso tì kí won wá ohun mìíràn se. Bí oba ti so eléyìí tán ni Dúdúyemí bá ki enu bo èsà ó sì so bí Òjélàdé se di ere àti bí ó se di òòni tí ó jé pé obìnrin kan tí ó lo da ògì nù ni ó jé kí ó yí padà di ènìyàn láti ipò òònì tí ó wà. Léyìn èyí ni Òjélàdé náà wá fi èsà so pé se kí òun náà wí o, sé kò níí sí nnkan. Oba, Dúdúyemí àti àwon ènìyàn ní kí ó máa wí. Bí wón ti gbà á láyè yìí ni Òjélàdé wá fi èsà wí pé Àmòó tí ó jé bàbá “Dúdúyemí di mààlúù ó sì wogbó lo. Ó ní nítorí ìdí èyí ni Dúdúyemí se ń hùwà bí eranko. Òrò yìí dun Dúdúyèmí. Àwon ènìyàn ń fi se yèyé wón sì ń fi owó fo Òjélàdé lórí. Dúdúyemí wá yo ìwo kan ní àpò, ó pe ofò kélékélé sí i ó sì so fún Òjélàdé pé kí ó tún ìtàn rè pa. Bí Òjélàdé ti fé máa pèsà báyìí, gbígbó ni ó ń gbó bí ajá. Ìyàwó rè, Ànséétù rí ohun tí ó ń se é, ó wá lo sí ibi òkètè oko rè ó sì mú oògùn kan jáde, ó bèrè síí pofò. Kò pé léyìn tí ó ti ń pofò yìí tí oko rè bèrè síí pèsà ó sì fi ewà ìyàwó rè wé ti Sábárúmó, ìyen fúlàní. Léyìn ìgbà tí Òjélàdé ti sojí yii ni ó wá so fún Dúdúyemí pé kí ó bá òun ki ‘Ìyèrú Òkún Olófàmojo nílé Olálomí’, ìyen oríkì ìyá oba. Bí Dúdúyemí se nì kí òun máa sòrò báyìí ikó ni ó ń hú tí èjè sì ń dà lénu rè. Gbogbo oògùn tí ìyàwó àti àwon omo èyìn rè se fún un kò sisé. Lékèe gbogbo ohun tí ó ń selè yìí orin ni Òjélàdé àti ìyàwó rè ń ko tí wón sì ń jó tí wón ń korin tí gbogbo ènìyàn sì ń wòran won. Nígbà tí ó se, obá so fún Òjélàdé pé kí ó tú Dúdúyemí sílè. Òjélàdé se bí oba ti wí. Oba wá so pé Òjélàdé ni ó yege ó sì fi je Baálè arèkú eégún. Dúdúyemí lo bá Òjélàdé ní ibi tí ó ti ń jó. Oba ní kí Dúdúyemí júbà fún Òjélàdé gégé bíi ‘Baálè arèkú eégún. Dúdúyemí sì se béè’. Léyìn èyí ni Òjélàdé wá fi èsà ki Ìyèrú Òkín Olófàmojo. Bí ó ti se èyí tán ni oba bá fi omo rè kan ta á lóre kí ó fi saya. Òjélàdé fi èsà dúpé lówó oba fún omo rè tí ó fún un yìí. Léyìn èyí ni Òjélàdé wá padà sí ilé. Nígbà tí ó dé ilé, ó lo kí baálè ìlú rè. Ó fi èsà dúpé lówó gbogbo àwon tí ó bá a wálé láti ìgbà tí ó ti joyè yìí ni kò ti lo sí òde eré mó. Pèlú owó tí ó ti rí, ó di onísòwò pàtàkì. Baálè nìkan ni ó sì lówò jù ú lo ní ìlú yìí. Àwon omo isé rè tí ó ń lo sí òde ijó sì wá ń fi àbò jé e, ìyen nip é wón wá máa ń fún un ní nnkan tí wón bá ti ti òde idán dé.

  1. Àwon Òrò tí ó Ta kókó

Òkèrè: Erù tí a dì sínú aso tàbí àpò tí ó rí bànbà. Irú àpò yìí ni àwon omo èyìn eléégún máa ń di erù ìpidán won sí (ojú-ìwé 3)

Awórintúnrinro: Àwon alágbède ni wón máa ń lo òrò yìí fún nítorí pé àwon ni wón máa ń lu irin tàbí pé kí won na irin tí wón sì fi ń ro nnkan (ojú-ìwé 3)

Soró: Kí ènìyàn se oró, ìyen igi oró agogo (ojú-ìwé 4)

Esèntáyé: Yíye ohun tí omo tí a sèsè bí yóò gbé ilé ayé se wò. Esèntáyé tí wón yé wo ni wón fi mò pé isé eégún onídán ni Òjélàdé yóò se (ojú-ìwé 6)

Kerèé: Fààfàá ni èyí. Tí onídán bá n pa idán, yóò ta ení fààfàá yíká ara rè yóò sì máa wó gburugbu lo. Èyí ni wón fi máa ń so pé ó ń wó kerèé Eléyìí nì Òjélàdé se tí ó fi di òjòlá tí kò sì lè padà di ènìyàn mó. Bàbá rè Òjè Lárìnnàká ni ó se é láìmò pé omo òun ni.

Ewúsà: Òkété ni ó ń jé weúsà (ojú-ìwé 26)

Abá-òwú: Irú idán ken tí onídán fi máa ń di abá-òwú nì yí. Òjélàdé di abá-òwú nínú idán tí ó pa, ìyen nip é ó di òwú gulutu (ojú-ìwé 27)

Èrùùgàlè-kó-dìde: Idán kan nì yí tí onídán yóò ti máa ga lo sókè bí àwon omo èyìn rè bá ti ń korin fún-un (ojú-ìwé 27)

Olúwéré: Igi ìrókò ni ó ń jé báyìí (ojú-ìwé 34)

Arèsà: Oba ìlú Ìresà. Òjélàdé ti jó ní iwájú rè rí (ojú-ìwé 41)

Ìròré: Orísìí eye kan tí ó kéré nì yí (ojú-ìwé 41).