Ire-Ekiti

From Wikipedia

Ire-Ekiti

F.I. Ibitoye

Ogun

F.I. Ibitoye (1981), ‘Ìlú Ìrè-Èkìtì’, láti inú ‘Òrìsà Ògún ní ìlú Ìrè-Èkìtì.’, Àpilèko fún Oyè Bíeè, DALL, OAU, Ifè, Nigeria, ojú-ìwé 1-3.

Ìrè-Èkìtì jé ìlú kan ní agbègbè àríwá Èkìtì ní ìpínlè Ondó; èyí tí ó jé òkan nínú àwon omo bíbí inú ìpínlè ìwò-oòrùn àtijó. Tí ènìyàn bá gba ojú títì olódà wo ìlú Ìrè, ó rí bi kìlómítà márùndínlógójì sí Ìkòlé-Èkìtì tí í se olú ìlú fún gbogbo agbègbè àríwá Èkìtì. Sùgbón ó fi díè lé ni ogóje kìlómítà láti Ilé-Ifè. Èyiini tí a bá gba ònà Adó-Èkìtì. Nígbà tí a bá gba ònà yìí, léhìn tí a dé Ìlúpéjú-Èkìtì ni a óò wá yà kúrò ní títí olódà sí apá òtún. Ònà apá òtún yen tí wón sèsè ń se ni a óò wá tò dé Ìrè-Èkìtì, kìlómítà márùn-ún ibi tí a ti máa yà jé sí ìlú Ìrè-Èkìtì.

Ara èyà ilè Yorùbá náà ní ilú Ìrè-Èkìtì wà. Àwon gan-an pàápàá sì tilè fi owó so àyà pé láti Ilé-Ifè ni àwon ti wá. Wón tún tenu mó o dáradára pé ibè ni àwon ti gbé adé oba won wa. Nítorí náà, títí di òní olónìí, Onírè ti Ìlù Ìre-Èkìtì jé ògbóntagi kan nínú àwon oba Aládé tí ó wà ní Èkìtì.

Gégé bí n óò ti se àlàyé ní orí kejì ìwé àpilèko yìí, “Oní-èrè” ni ìtàn so fún wa pé wón gé kúrú sí “Onírè” ti ìsìnyìí. Alàyé Samuel Johnson nínú The History of The Yoruba. sì ti fi yé wa pé nítorí orísìírísìí òkè tí ó yi gbogbo èyà Yorùbá tí à ń pe ní Èkìtì ká, ni a se ń pè wón béè. Nítorí náà, orúko àjùmo jé ní “Èkìtì”. Ìtàn sí tún fi yé mi pé ìlú kékeré kan tí ó ń jé “Igbó Ìrùn” ni àwon ará Ìrè-Èkìtì ti sí wá sí ibi tí wón wà báyìí; àìsàn kan ló sì lé won kúrò níbè. “Igbó Ìrùn” ti di igbó ní ìsinyìí, sùgbon apá àríwá Ìrè-Èkìtì ló wà. Mo fi èyí hàn nínú àwòrán ìlú náà.

Ìsesí àwon ará Ìrè-Èkìtì kò yàtò sí tí àwon ìlú Yorùbá yòókù, yálà nípa aso wíwò tàbí àsà mìíràn. Àrùn tí í sìí se Àbóyadé, gbogbo Oya níí se. Àwon náà kò kèrè nípa gbígba èsìn Òkèèrè móra nígbà tí gbogbo ilè Yorùbá mìíràn ń se èyí. Esìn Ìjo Páàdi àti ti Lárúbáwá ni a gbó pé wón gbárùkù mó jù. Síbèsíbè, wón sì ń ráyè gbó ti èsìn ìbílè Yorùbá, bí ó tilè jé pé ó ní àwon àdúgbò tí èyí múmú láyà won jù. Fún àpere, mo toka sí àwon àdúgbò tí won ti mò nípa Òrìsà Ògún dáadáa nínú àwòrán.

Èdè Èkìtì nì òdè Àdúgbò won. Nítorí náà, ìyàtò tí ó wà láàrin èdè Èkìtì àti ti Yorùbá káríayé náà ló wà ní tiwon. Fún àpeere won a máa pa àwon kóńsónàntì kan bíi ‘w’ je. Won a pe “owó,” ‘Òwírò’ “Àwòrò” ni “eó”, “òúrò”, “Àòrò”. Wón tún lè pa ‘h’ gan-an je; kí wón pe “Ahéré”ní “Aéré. Nítorí náà “Aéré eó” yóò dípò “Ahéré owó”

Nígbà mìíràn pàápàá, won a fi eyo òrò kan dípò òmíràn, fún àpeere:

ira yóò dípò ará

erú yóò dípò erú

èyé yóò dípò ìyá.

àbá yóò dípò bàbá

ijó yóò dípò ojó


Gégé bí a se mo, àwon náà tún máa ń fi fáwélì ‘u’ bèrè òrò. Fún àpeere:

Ulé dípò Ilé

Ùrè dípò Ìrè

Ufè dípò Ifè

Ukú dípò Ikú


Òpòlopò ònà ni èdè yìí fi yàtò si ti Yorùbá káríayé. Nítorí náà, mo kàn sì ń se àlàyé rè léréfèé ni, n óò tún máa ménu bá wón nígbà tí a bá ń se àtúpayá èdè orin Ògún. Òrò pò nínú ìwé kóbò ni.