O.A. Aboderin: Gbolohun Ibeere
From Wikipedia
O.A. Aboderin Gbólóhùn Ìbéèrè Àtúnyèwò láti owó Oláníyì O.A. Aboderin (1995) “Ònà Ìsèdá Gbólóhùn Ìbéèrè nínú Èdè Yorùbá”, Àpilèko fun Oyè Emeè, DALL, OAU, Ife, Nigeria.
ÀSAMÒ: Ète ìsé yìí ni láti se àfihàn bí tíórì ìjoba àti àdìpò se sisé sí lórí àlàyé ìhun gbólóhùn ìbéèrè oní-ni tí à ń sèdá nínú ìpèdè ojoojúmó l’èdè Yorùbá. Tíórí ìjoba àti àdìpò yìí ní àwon òté, ìlànà àti òfin kan tí o gbé kalè fún àtúpalè ìhun gbólóhùn. Irú àgbékalè yìí ń sàlàyé òfin tó de àgbéfò bíi: Ìdí tí o fi wáyé tàbí tí kò fi lè wáyé nínú ìhun. Ní ònà kejì; a lo tíórì onípele tí o jé ohun èlò fún tíórì ìjoba àti àdìpò. Láti sàlàyé ìfarakínra òrò nípasè ikómúpò àti ìgàba, ìdè ìso itókasí, ìjoba, àse omo-inú, àse ìpèkun àti béè béè lo. A lo tió rì yìí láti sàlàyé òté ìsòrí òfo, òté ìhun òkè, ààlà àgbéfò tí kání isúnmóra. A lérò pé isé yìí yóó se àfihàn ibi ti girama ìjoba àti àdìpò sisé dé lórí gbólóhùn ìbéèrè èdè Yorùbá.
Lénu ìwádìí yìí, a se àkójo àwon ìwé tó se kókó lórí tíórì yìí gégé bíi ìpìlè fún isé wa. A tún lo àwon ìbéèrè tí a gbó lénu àwon elédè nínú àlàyé isé náà. ìmò wa gégé bí omó Yorùbá náà tún ràn wa lówó, pàápàá láti sàlàyé ìbófinmu àti àìbófinmú àwon gbólóhùn ìbéèrè oní-ni.
Isé yìí fi hàn pé, bí ìhun gbólóhùn ìbéèrè oní-‘ní’ se pò náà ni àgbéfò pe orísìírísìí. Ó sì tún fi hàn pé òpòlopò àwon òté, ìlànà àti òfin tí tíórì ìjoba àti àdìpò ń lò, ló sisé lórí èdè Yorùbá, bí o tilè jé pé àwon àfi kòòkan náà sì wà.
Ní sókí, isé yìí fi hàn pé tíórì ìjoba àti àdìpò dára ní tòótó sùgbón ipò rè gégé bíi tíórì káríáye nílò àtúnyèwò. Nítorí òpò àwon òté àmúlò tíórì ìjoba àti àdìpò fún èdè Yorùbá ló sì nílò àtúnse. Bákan náà ni tíórì ijoba àti àdìpò tún lè jé ìpìlè láti sàlàyé ihun gbólóhùn lápapò nínú èdè Yorùbá.
#Orúko Alábòójútó: Professor L.O. Adéwólé #Iye Ojú Ewé Ìwé: Aárùn-ún-dín-lógóje (135).