Ebo Riru
From Wikipedia
EBO RÍRÚ
A lè kí ebo rírú gégé bí ìgbìyànjú èdá láti mú nínú nnkan ìní rè bi: owó, aso, oúnje, epo, eja, eran àti ògòòrò irúfé àwon nnkan mèremère mìíràn tí ó wà ní ìkáwó èdá fi tore fún aládùúgbò rè tàbí eranko àti òkànlénírinwó àwon èmí àìrí wòn-on-nì tí a gbàgbó pé wón lágbára láti tún ayé eni se tàbí láti mú kí olúwarè ó ma rí bátisé e. kì í se àwon tí kì í se onígbàgbó tàbí Mùsùlùmí nìkan ló máa ń rú ebo. Gbogbo èsin ni ebo rírú je lógún, tí ó sì múmú láyà won bí omo túntún.
Ebo rírú kò yo enìkankan sílè rárá. Ibi gbogbo ni à ń kó adire alé ni òrò ebo jé fún èsìn àbáláyé, èsìn kiriyó àti èsìn Mùsùlùmí. Orúko àti ònà tí èsìn kòòkan ń gbà láti rú ebo tirè ló lè yàtò sí ara won. Eni tí ó rúbo ni Èsù ú gbé. Rírú ebo ní í gbeni, àìrú rè kì í gbe ènìyàn. Fún àpeere, àwon alàwòrò tàbí omoléyìn Mòhámédù máa ń se sàráà ni gbogbo ojó Jímò. Wón á dín mósà lo sí akòdì ìjósìn won fún Jànmó-òn láti je. Bákan náà ní àmòlà kì í gbéyìn rárá. Bí Mùsùlùmí bá kó kéwú dé oríkèé kan, won a omo èkósé kéwú ó se sàráà; èyí tí won ń dàápè ní “Wòlímò” omo kéwú yìí lè pa adìe tàbí eranm àgbò. Bí ó bá tún kéwú náà síwájú sààà tàbí tí ó tán kùránì, wón a pa màlúù. Ebo rírú ni gbogbo ìnáwó wònyí.
Bí ó bá tún di àkókò odún iléyá àti odún ìtúnu ààwè, àwon omoléyìn Ànábì Mòhámédù a tún pa eran, won a ta èjè sílè. Won yóò há eran yìí fún àwon aládùúgbò won bí ó ti to àti bíu ó ti ye. Ìyá-Súnà, gbà, eran odún re nìyí. Ìyá-Káà, gbà o, tìe nìyí. Tí ìyá Súnà àti ìyá Káà bá gba eran odún tán, won a ní enu òbe kò ní í sélè o, àse. Ebo rírú kan kò ju èyí lo. Onígbàgbó tàbí àwon àwòrò Jésù náà ní àkókò odún Kérésìmesì, odún ajínde tí won fi ń kóta ikú Jésù àti àjòdún ìkórè ní òpin odún. Wón máa ń peran tí won ó sì wá oúnje pèlú nnkan yòówù tí wón bá tún nípá láti mú wá sí iwájú pepe. Won a ní àwon ń dáná odún, e n só nílé bàbà ìjo kí á lo jó tàbí je oúnje odún. Sàká tàbí ìdáméwàá yíyo nínú nnkan yówù tí èdá ba ni láti fi dúpé tàbí tore pín lára àbùdá ebo rírú bakan náà.
Gégé bí Gíwá Ifáfitì Ifè, Olóyè, Òjògbón Wándé Abínbólá tí so: ebo Yorùbá kì í se ebo tí a rú láti dá ènìyàn nídè kúrò nínú ìgbèkùn èsè rè. Sùgbón èyí kì í se ti òrò èsìn Kiriyó àti èsìn Mùsùlùmú. Tí Mùsùlùmí bá sèsè ba ìyàwó won lò pò tán, wón níláti we Jínníbà kí won ó tó lo sí akòdi ìsìn won. Àwon ìgbàgbó ìjo Mímó láti òrun wá (Celestial Church of Christ) àti ìjo Kérúbù àti Séráfù náà máa ń we irú ìwè yìí; won a ní a kò gbodò gbé ara àìmó wo ilé ìjósìn.
Síwájú sí i, àwon ìjo Aládùúrà àti ìjo Àpóítélì lè wí pé kí alàwòrò won lo wè ní odò tó ń sàn tàbí kí won lo fi iye àbélà kan gbàdúrà kí olúwarè lè rí ìdándè tàbí ìségun gbà. Ebo rírú ní gbogbo nnkan wònyìí. Òrìsà tàbí àwon ìbo mìíràn bíi Sàngó, Ògún, Òrúnmìlà abbl. ni oroorún, tí a sì ń yánlè oúnje fún òkú-òrun pèlú nígbà gbogbo tí a bá ń jeun. Bákan náà ni Yorùbá tún máa ń pa èyìn arúgbó won dà tó tí papòdà ni ìbámu pèlú ìgbàgbó nínú àjínde òkú pé ikú kì í se òpin èdá ni ayé.
Òrìsà kòòkan ló ní oúnje tirè tí ó féràn láti máa je. Nnken tí ara Eégún gbà, ara Orò lè kò ó. Èyí wù mí kò wù ó ni kò jé kí omo ìyá méjì pa owó pò fébìnrin. Fún àpeere. Okà tàbí Àmàlà, gbègìrì àti eran àgbò ni Sàngó, Olúkòso Arèkújayé Onílagbàjìnnìjìnnì féràn; Ògún Onírè féràn emu àti eran ajá; Eégún a sì máa gba èkuru, otí pèlú obì. Òrúnmìlà a máa gba:
Eku méjì Olùwéré,
Eja méjì abiwègbàdà;
Ewúré méjì abàmú rédérédé;
Einlá méjì tó fiwo sòsùká;
Eye méjì abìfò gàngà.
Ata tí ó síjú,
Obì tí ó làdò,
Otí àbodà.
Ní ònà kejì, ebo rírú wà fún ìtooro ààbò àwon ìbo àti òkú-òrun lórí odidi ìlú tàbí eníkòòkan wa. Ebo ni òjá tó so wá pò mó àwon Irunmole wònyìí. Nípa ebo rírú ni a lè fi ségun àwon ajogun. Bí a bá ti rúbo tán, dandan ni kí àwon Ajogun (Òràn, Èpè, Òfò Àrùn, Èse, Ikú, Egbà àti Èwòn) ó padà léyìn eni tí won ń se. Eni tí ó bá rúbo ni Èsù ú gbè. Ìdí nìyí tí Ifá Olókun, Asòròdayò fi so wí pé:
Onídúdú gba dúdú
Onípupa gba pupa,
Aláyìnrín gbàyìnrín.
Báràápetu, ò bá mò mò kókú o kárùn,
Báràápetu.
Ní ònà keta, ebo rírú máa ń ran ìpín tí enìkòòkan wa yàn láti òrun lówó láti má jèé kí í fi orí sánpón. Bákan náà ló tún ń jé kí aburú tó wà nínú ìpín wa ó féri. Ebo rírú yìí ní ó máa ń fa aso òfò wa ya. Bí ó ti wù kí oòrùn ó mú tó, sánmò dúdú díè yóò wà, bí ó ti wù kí ayé wa láyò, yóò ní àkókò ekún rè. Rírú ebo yìí ló máa ń dín àkókò ekún kù nínú ìgbésí ayé omo èdá. Rírú ebo ní í gbeni, àìrúi rè kì í gbe ènìyàn. Ese wúrà kan láti inú ìwé mímó àwon Yorùbá. Ifá tilè fi yé wa pé ìpààro ara eni ní ebo-rírú jé. Nígbà tí àwo a jogun bá dé, tí won sì gbógun tin i, bí a bá fi nnkan ìní bí owó, aso, eja, eran, epo tàbí nnkan mìíràn kébo rú, tí Esù bá sì ti gba ebo náà tí ó gbé e fún àwon ajogun, dandan ni kí won ó pèyìndè, kí won ó si lo. Esù Ifá náà lo báyìí:
………………………………………….
Pààrò pààrò, awo ilé Elépè,
Àrùn wáá fElépèé í lè,
Orí eran ló mú lo.
Pààrò paaro, awo ilé Elépèé
Òfò wáá fElépèé í lè,
Orí eran ló mú lo.
Pààrò paaro, awo ilé Elépèé,
Ajogun gbogbo wáá fElépèé í lè,
Orí eran ló mú lo,
Pààrò paarò, awo ilé Elépè.
Ní ònà kerin, ebo jé oúnje pàtàkì fún àwon babaláwo pàápàá. Irú nnkan báyìí tí babaláwo máa ń rí mú sílè lára ebo ni Yorùbá ń pè ní èrù. Níwòn ìgbà tí ó jé wí pé babaláwo tó jé oníwòsàn àti onísègùn ìsèse ní ilè Káàárò-Oòjííire kì í gba owó òya èrù yií ni wón ń je. Ìdí nip é eni tó bá se ni ibi pepe ní í je níbi pepe. Sùgbón ohùn kan tí ó jé dandan ní owó orí òràn-an-yàn ni aso ìbora nip é Òrúnmìlà gbódò fún awo ní àse láti mú nínú nnkan tí oníbèérè fi rúbo kí ó tó dip é wón lè mú níbè kànńpá ni èyí. Ìdí nip é ki í se gbogbo ìgbà ni àwòrò Ifá ní ànfààní láti mú nínu nnkan tí a fi rúbo. Bákan náà ni àwon awo gbódò kókó yo tí àwon ajogun àti ti Esù pèlú àwon ìbo gbogbo sótò kí won ó tó mú tiwon nínú ebo náà. Ifé ní ti Opón bá téjú tán, Awo lè je:
Òtítí baba ajé
Ológìnìnginnì Aso Ràdà àti
Àkónkótán ohun òrò nIfè.
Ní àfikún, ebo jé ìpèsè oúnje fún enu omo aráyé. Ènìyàn kì í je ògèdè kó wú ni léèkà eru omo aráyé lebo. Ebo rírú kò wà fún àwon ìbo enu aráyé náà kí á máa baà rí ìjà won. Enu tótó fun – ùn. Enu tó so igbá di ògbún tó tún so ògbún di ìgbako. Ìgbàgbó Yorùbá ni pé tí enu bá je tán, ojú yóò tì. Àwon omo aráyé yóò sì súre fún eni tí ó rúbo. Ifá Olókun Asòròdayò ní:
………………………………….
N jé kín là ń bo nÍfè?
Enuu won.
Enuu won là ń bo nÍfè,
Enuu won
Mo fúngbá,
Mo fáwo.
Enuu won,
Enuu won kò mà lè rí mi bá jà.
Enu won.
Mo wálé,
Mo wánà.
Enuj won,
Enuu won kò mà lè rí mi bá jà.
Enuu won.
Síwájú sí i, ebo rírú tún se pàtàkì nítorí pé ó jé oúnje fún àwon eranko bíi ajá àti eye ojú òrun bìí igún. Eranko bíi ajá àti eye igún féràn ebo jíje. Ìdí nìyí tí a fi máa ń so pé
Nnken ti ajá ó je Èsù ó wá a.”
Ese Ifá kan tún se àlàyé síwájú lórú òkodoro òrò yìí láti fi òtító múlè wí pé bí a kò bá rí gúnnugún, a kò le è se ebo, bá ò rákàlàmàgbò, a ò sorò. Ese Ifá náà lo báyìí:
Sàlàgbèrèjè ló dífá fún gúnnugún,
Omo olójògbòòlórò.
Sàlàgèrèjè wáá jebo…
À sé bá ò rí gúnnugún,
A kì yóó lè sebo.
Bá ò rákàlà,
Sàlàgbèrèjè wáá jebo.
Igún wáá jebo,
Kébo ó lè baà fín.
Ètìé wáá jebo,
Kébo ó lè baà dà
Igún, ètìé, aráà Lódè.
Sàlàgèrèjè wáá jebo.
Oògùn wà ní lílò ní ìgbà tí ojó bá pedí. Sùgbón nígbà mìíràn ewé lè sunko. Ebo kì í bà á ti. Ìdí nìyí tí àwon Yorùbá kì í fi sahun ebo rírú. Osanyin ni baba ìsègùn; Ifá Olókun Asòròdayò, Akéréfinúsogbó, Akónilóràn-bí-ìyekan-eni, okùnrin kúkúrú òkè ìgélì, Alóhun-orò-jegbé-ro-lo ló ni ebo. Ìdí nìyí tí Yorùbá fi máa ń wí pé:
Sarí má saàgun.
Oògùn ló ni ojó kan ìpónjú
Ebo àti orí ló ni ojó gbogbo.
Rirú rè kì í gbe ènìyàn.
Ní ìkádìí, bí a bá ti gbó rírú ebo tí a rú, tí a gbó itú àtùkèsù tí a tù, tí a sì tún gbó òkarara ebo tí a há a fún àwon ìbo, òkú-òrun, ènìyàn àti eraniko igbé tán, nnkan tí ó kù ni kí òfò, òràn, epè, àrùn, ikú, èse, èwòn àti ègbà ó máa gbé igbé wo wá kí towó-tomo ó wolé wá bá wa. Ire nínú ni ìgbèyìn eni tí ó yan orí rere, tí ó fi apá àti esè se akitiyan tí ó gbámúsé, tí ó sì fí àyà yan òré tí ó ní láárí, tí ó sì tún rú ebo. Èyí náà ló dífá fún ògòòro ese Ifá tó máa ń parí pèlú ire. Fún àpeere
(i) Rírú ebo,
Àtètè tù èrù,
E wáá bá ni ní jèbutu ire.
(ii) Ilé nìyí òun aya ò,
Ilé nìyí òun omo
Èèyàn èé se fíyà láìnílé.
Ilé nìyí òun omo.
(iii) Ire méta làwá ń wá,
Àwá ń wówó o,
Àwá ń wómo,
Àwá ń wá àtubòtán ayé.
Eni tí ó bá pe awo lékèé, tí ó pe Èsù lólè, tí ó wo òrùn yànyàn bí eni tí kò ní í kú mó, tó ko etí ògbon-in sébo, ó di dandan kí àwon ajogun pa àgó tí olúwarè. Ìdí nip é bí a bá seni lóore tí kò dúpé bí olósà kó ni lérù lo ni. Bí a bá sì se é ni ibi náà kò láìfí. Ònà láti fi èmí ìmoore hàn, kí á sì tún tooro ààbò àti ojú rere àwon èdá tí a rí àti èyí tí a kò rí ni ó bí ebo rírú.
àjosepò òkú òrun àti ará ayé ìpàdé - àpèje
Ki o le gbé òràn fò ni
Kì í se fún ìdáríjì èsè tí
a ti se bí i tí àwon omo
léhìn Jéésù.
Báre Atóyèbí
ÌTÓKA
E.B. Ìdòwú: Olódùmarè: God in Yoruba Belief
Wándé Abimbola: Ifá: An Exposition of Ifá Literary Corpus.
Ìjìnlè Ohùn Enu Ifá, Apá Kínní
Ìjìnlè Ohùn Enu Ifá, Apá Kejì
Àwon Ojú Odù Mérèèrìndínlógún