Gelede

From Wikipedia

G,O, Fayomi

Gelede

Fayomi

G.O. Fáyomí (1982), ‘Gèlède, láti inú Gèlède ní Ìlú Ìmèko-Ègbádò kétu?’, Àpilèko fún Oyè Bíeè, DALL, OAU, Ifè, ojú-ìwé 1-10.

A. ÌTÀN ÌGBÀ ÌWÁSÈ NÍPA GÈLÈDÉ

Gèlèdé jé òrìsà kan pàtàkì lára àwon ìrìsà ilè Yorùbá; tí púpò nínú àwon omo káàárò-óò-jíire tí won ń se àgbéyèwò àsà àti òrìsà ilè Yorùbá kò kobi ara sí. Àwon díè ti ko nnkan sílè nípa gèlèdé nínú àwon ìwé àtìgbàdégbà bí “Odu” àti àwon ìwé tí won se fún títà lórí àte fún ànfààní àwon akékòó Ìjìnlè Yorùbá. Àwon àkosílè bá yìí gbìyanjú láti fi irú òrìsà tí gèlèdé jé hàn. Pèlú ìdánilójú ni won fi so pé “Ojú tó wo gèlèdé ti dópin ìran wíwò”2 Ìdí pàtàkì tó sàlàyé òwe yìí kò ju pé àwon èyà ara pàápàá tí obìnrin, ló jé ohun tí won nánní jù tí won kì í sì fi í sílè láìfi aso bò ó. Sùgbón èyí kò rí béè pèlú gèlèdé nítorí gbogbo ohun àmúsògo èyà ara okùnrin àti obìnrin bí omú, ló máa ń sI síta láì fi aso bò. Fún èyí, ojú tó bá ti rí òkun, kò lè rí àsà kó tún bèrù. Bí ó tilè jé pé púpò nínú ìtàn tí àwon olùwádìí àsà àti òrìsà ilè Yorùbá ko nípa gèlèdé jo ara won, síbè a kò sàìrí ìyàtò díèdíè nínú àwon ìtàn won. Àwon ìyàpa tàbí ìyàtò ti a ń rí tóa sí nínú irú ìtàn wònyí ló mú mi pinnu láti lo sí ìlú Ìmèko, ibi tí àwon onígèlèdé gbà pé ó jé ìbátan Kétu níbi tí gèlèdé ti sè lo so ìwádìí. Alàgbà Asíímì Olátúnjí tó jé eléfè àti àwon onígèlèdé méjì tí mo fi òrò wá lénu wò nípa ìtàn tó rò mó bí gèlèdé se bèrè ní Ìmèko ni wón wí pé orí àwon baba ńlá a wa ló ti bèrè ní ìlú Ìmèko, ní àkókò tí enìkan kò lè so pàtó nítorí ojó ti pé. Níwòn ìgbà tó jé pé èrí àtenudénu ni nnkan tí alàgbà yìí fún mi, tí èrí àtenudéu sì jé òkan pàtàkì nínú èrí tí eni tó bá ń se ìwádìí nípa ìtàn orílè-èdè tàbí èyà kan kà sí èyí tó se é gbékèlé n kò lè kóyán ohun tí alàgbà yìí so kéré nínú ìwádìí mi. Alàgbà Asíímì fi yé mi pé láti inú òkun ni òrìsà yìí ti wá. Ìdí nìyí tí won sì máa ń so pé “Oloókun dé o, Àjàró òkòtó” nígbà yówù kí gèlèdé dé ojú agbo. Ó tún fi yé mi pé eré ni wón máa ń fi se níbèrè léhìn tí àwon baba wa bá ti enu isé òòjó won dé lálé nígbà tí owó bá dilè. Kò sí orísìí ìlù tí Olókun kìí lù. Léhìn-ò réhìn àwon baba wa lo fetí sí bi Olókun Sèníadé se ń lùlù láti mo bí àwon náà se lè máa lùlù fún gèlèdé tí àwon ń se. Bómodé bá bá ìpele aso ìya rè kò ní si aso dá ni òrò yìí wá dà. Ohun tó jehun la fi ń wéhun: léhìn tí won gbó bí Olókun se ń lùlù, wón gé igi ìbépe, wón sì fi awo bòó lójú kí won lè máa rí nnkan lù bí won bá ń se eré yìí. Èyí nìkan kó, ń so saworo òkòtó mó orùn esè won, pèlú ère ní orí won àti òpòlopò aso ní ara won. Bí ilè se ń mó ni ogbón ń górí ogbón síi. Láìpé, àwon baba wá rí i pé igi ìbépe yìí kií tó; wón fikùn lukùn lórí àyípadà tí won lè se kí ìlù yìí lè máa tójó. Níbi ni wón ti jáwó nínú ààpòn tí kò yò tí won dámi ilá kaná. Wón pa igi ìbépe tì, wón wá ń fi igi òmò gbé ìlù kó lè máa tó. Kìí se ìlù níkan ni kìí tójó. Wón sàkíyèsí pé saworo òkòtó tí won n so mésè náà kìí tójó. Èyí ko wón lóminú. Pèlú inú fù, èdò fù ni wón fi n jíròrò lórí àyípadà tí àwon lè se àti ohun tó lè dípò saworo yìí. Ìdí nip é gbogbo ìgbà tí won bá fé jó ni won níláti wá saworo lo torí èyí tí won ń lò yóò ti peyo tàbí kí ó fó tán. Wàhálà ńlá gbáà ni kí a máa wá saworo kiri ní gbogbo ìgbà jé fún ará ìlú, nítorí ó ti di dandan kí won fesè kan dé òkun nígbà yówù kí won fé jó gèlèdé. Sùgbón orí tí ò bá la ni ní í gbé aláwore ko ni ni òrò àwon ará Ìmèko jé nígbà tí àwon ará ìlú Ìlóbí ní etí Ìláròó Egbádò wá bá won pé àwon fé kósé gèlèdé lódò won. Bí ìtàn tí mo gbó, isé àgbède ni isé àwon ará Ìlóbí, òrò wá di kí òtún we òsì, kí òsì we òtún èyí tí owó fi ń mó. Àwon ará Ìmèko gbà láti kó àwon ará Ìlóbí ní gèlèdé lórí àdéhùn pé àwon Ìlóbí yóò bá àwon ro “Ìkù” kí àwon ri nnkan dípò saworo àkòtó. Kò sí àbùjá lórùn òpè fún àwon ará Ìlóbí ju kí won gba ohun tí Ìmèko wí lo. Báyìí ni kì se dípò saworo òkòtó tí wàhálà a ń wá saworo kiri kúrò nínú òrò gèlèdé Ìmèko. Ìtàn mìíràn tí mo gbó lénu alàgbà Odemúyìwá Ògbóntàgi Onígèlèdé ìlú Ìmèko fi yé mi pé ílú Kétu ni gèlèdé ti sè, kódà ó ko orin tó fi kín òrò rè léhìn pé:

“Omo Oba Kétu

Omo Olúwa Ojà

Omo tó wúwo bí akoni òkúta

Omo gèlèdé tó gorí oyè lójó sí

Lóhòrí ilé

Tó bo ègbà sésè rè

Oníjó, omo ère tó ń mólá wá.”

Alàgbà yìí ní nígbà tí won ti dá ìlú Ìmèko sílè ni gèlèdé ti bèrè nítorí àwon omo Alákétu tó wá te ìlú Ìmèko dó ló mú eré yìí wá. Ó tún so síwájú pé ohun tí a kò mò ni a kò mò, ajá inú ìwé kó ló máa bun i je. Ó ní eré omodé ni gèlèdé níbèrè pèpè nítorí àwon omodé méjì kan ló máa ń fi seré, wón á sì so saworo òkòtó mó orùn esè won. Bí won bá ń jó, won a máa fi esè janlè, saworo esè won á sì máa ró. Mo wá se ìbéèrè pé: “Báwo la se ńm pín itan elédè tó fi ń kan lèmómù nípa kíki gèlèdé kan Olókun?” Alàgbà yìí ní kíki gèlèdé kan Olókun kò sàìní í se pèlú saworo òkòtó òkun tí won ń so mésè fi jó ijó yìí. Ìdí nìyí bí gèlèdé bá dé agbo tàbí bó bá ń jó won a máa wí pé “Olókun dé o, àjàróòkòtó” nítorí inú Òkun ni wón ti ń rí saworo yìí. Àwon omodé ló ti máa ń fi gèlèdé seré típétipé kí ogun Ìdòòmì tó bé sílè tí àwon tó ti ogun dé náà sì tún wá ń fi eré yìí dárayá léhìn ogun. Ohun tí a lè fà yo nínú ìtàn alàgbà yìí kò ju pé àwon ará Ìdòòmì tó ń gbé Kétu ló ti ni gèlèdé kí àwon omo Odùduwà tó dé wá lé won jáde kúrò ní ìlú won. Báyìí ni àwon “sèsèdé” wònyí se gba àsà tí won bá lówó àwon tí won lé jáde tó sì di tiwon.


B. BÍ GÈLÈDÉ SE DI ÒRÌSÀ

Ìdálùú ni ìsèlú, bí a se mò nínú àsà àtayébáyé Yorùbá pé kò sí ohun tí won máa dáwó lé tí won kò ní bèèrè lówó Ifá nítorí òun ni “Òpìtàn Ìfè” “Akéré finú sogbón”. Akónilóràn bí i yèkan eni.” Òun sì ni “Gbólájókòó omo èokinkin tíí mérin fon.” Àwon Ìmèko náà máa ń se é bí won se ń se é kó lè rí bó se máa ń rí. Wón máa ń won ara wò lódò Ifá kí won tó dáwó lé nnkan. Fún ìdí pàtàkì yìí, kí won tó jó gèlèdé wón á kó eéjì kún eéta, ó doko aláwo. Babaláwo ni yóò wá so fún won pé kí won rúbo sí àwon tó se gèlèdé kí ìlú lè tùbà tùse; kí òjò àsìkò lè rò sórí irè oko; kí òfò, èwòn, àseìrí àti àrùn burúkú lè máa finú igbó se ilé, kí won sì máa gbé òkèrè wo gbogbo ará ìlú. Kò kúkú sí nnkan méjì tí won ń bo lálè Ifè ju enu lo. Rírú ebo ló sì ń gbe ni, àìrú kì í gbènìyàn. Nítorí pé òrò Babaláwo máa ń se bí àwon ará ìlú bá gbó rírú ebo tí won rú, tí won sì gbó ebo àtùkèsù tí won tù, ìgbàgbó won nínú gèlèdé gbilè. Báyìí ni wón gbé ère gèlèdé tí won sì kó won sí ibi tí à ń pè ní “ASÈ” ti igi gèlèdé di ohun àpébo bi Babaláwo kò tiè pa á láse fún won. Bí a bá ni ònà dé orí òpe pin bí i ti gèlèdé yìí kó nípa bí ó se di òrìsà. Obìnrin lèké, òun lòdàlè, isé tó bá rò ni òle won ń wá se. Èmi lè jó, ìwo lè lù, kòkòrò méjì ló pàdé ni òrò gèlèdé àti àwon obìnrin jé nítorí isé ijó ni. Àwon obìnrin féràn ijó nítorí pé ó fi àyè sílè fún won láti se gbogbo fáàrí tí won bá mò, won á sì ráyè rera dáadáa; wón á sì ráyè gbé apá fújì genge han àwon aráyé. Bí won bá ráyè su tán, ń se ni wón ń dáwó telè. Gégé bí ìfé tí àwon obìnrin ní sí ijó jíjó, wón gba gèlèdé kanrí débi pé ó di òrìsà “obìnrin”. Àdàpè olè tó ń jé pé omo ń féwó ni “obìnrin” tí à ń lò túmò sí nínú òrò gèlèdé. Nnkan tí “obìnrin” dúró fún nínú gèlèdé ni àwon “ÀJÉ”. Orísìrìísi orúko ni àwon Onígèlèdé sì máa fi ń pè wón nítorí eni tó mo etu ló ń kìí ní òbèjé. Fún àpeere àwon ni “Ìyáńlá”, Ìyá mi”, “Ìyá Àgbà”, “Olórí eye” tàbí “Òsòròngà”. Bí a bá wo nnkan tí ònkówè kan wí nípa Sàngó pé:

“Òrìsà tí Sàngó kò lè nà

Eré kó ló lè sá

Ó mobì pa fÓlúkòso ni.” 3

Báyìí gan an ni òrò àwon “Ìyàmi” rí: eníkéni tí kò bá fi tiwon se ara ikú ló ń yá a. Ìdí pàtàkì yìí ni àwon Onígèlèdé se kókó ń júbà fún won bí won bá dé agbo pé:

“Ìbà ìyá erí n rè é

Àpàké erí n rè é awo ìyá

Ìyá alégi àpólà ńlé

Ìyá Onírunbé Òsùsù afèjè àlà

Omiigbóná kò se í un kíòkíò

Eléye ègà límògú è gbawo se

Lè sí kó pé tiyín bá sí?

Eégú ó lí tìyá kò soro aso a ha mú lójú

Òrìsà ó lí tìyá kò soro enu ilé è a huko.”

Káàkiri ilè àláwò dúdú tó fi ken ilè Yorùbá ni wón gbàgbó pé àwon àjé wà, wón sì ní agbára àìrí tí won fi ń se ènìyàn níbi. Níbi tí agbára won tilè dé, wón lè pa kádàrá ènìyàn dà, wón lè ba irè oko jé, wón sì lè fi àìsàn burúkú se ènìyàn. Ònkòwé kan tún fi yé nip é “a-se-burúkú-se-re” ni àwon àjé nítorí bí inú won bá dùn sí èèyàn aburú kan kò ní dé sàkání onítòhún.4 Ìfé tí àwon “obìnrin”ni sí ijó yìí ló ń fún won ní ànfààní àti fi agbára àìrí won se eni tí won bá fé lése. Èse yìí lè jé àìsàn, nígbà míràn ó lè jé pé obìnrin yóò yàgàn, bó bá gbó pó, kó mò pé òjò ló kán. Gbàrà tí àìsàn òjijì bá kolu ènìyàn gbogbo ìlàkàkà rè kií jú kó lo sódò Babaláwo láti lo ye ìpònrí ara rè wò. Arínú rode, eni tó mòrò ìkòkò ju ti gbangba lo ni Ifá. Bá yìí ni won yóò topa àrùn tàbí àìsàn yìí dódò àwon “Ìyàmi”. Babaláwo ni yóò wá ka nnkan ebo tí aláìsàn yóò lo fi bo gèlèdé láti petù sínú àwon ìyáńlá. Bí aláìsàn bá ti bo gèlèdé tán ni àwon “Ìyá” to ta kókó ìsòro fún un yóò tú u sílè. Kèrè kèrè kéré se títí ó di òkéré; ohun àmúseré wá di òrìsà àkúnlèbo sígbá gbogbo ará ìlú. Báyìí ni òjé se wo owó àwon obìnrin tán tó wá ku baba ńlá eni tí yóò bó o.

D. ÀWON TÓ Ń SIN ÒRÌSÀ YÌÍ

Bí ohun tí a ti gbó télè pé àwon àjé gan an ni wón forí pamó sábé gèlèdé tó fi di òrìsà, kò sí eni tí kò lè nípa nínú sínsin òrìsà yìí pàápàá gbogbo eni tó bá ń fé ààbò lódò àwon Ìyá ńlá, yálà okùnrin ni tàbí obìnrin, omodé tàbí àgbàlágbà. Kò síbi tí owójà erin kò tó ni òrò àwon àjé. Sùgbón bí èèyàn bá ti ń rawó rasè sí won tirè á di àwònù àwònù tí ekùn ń weye òkè lówò won. Kí a wá ye ti àwon “e-kálo-késè-pò” àti àwon tó ń forí ara won pamó wònyí kúrò, àwon tí a lè pè ní olùsin gèlèdé gan an ní ìlú Ìmèko ni àwon tó ń kóbì kó orógbó bo òrìsà yìí lóòrè kóòrè. Wón yàtò sí àwon abánikéyèe gèlèdé tàbí àwon omo ìlú Ìmèko mìíran tí won ń tìtorí pé gèlèdé jé òrìsà gbogbo ìlú fi enu pe ara won ní omo tàbí Onígèlèdé. Yorùbá bò, wón ní bí gbogbo omo awo bá jé elégùn òrìsà, tan i yóò ké héèpà!? Ìdí nìyí tí àwon olùsìn àwon òrìsà ní ilè Yorùbá bí i Onísàngó, Olóya, Eléégún àti Olórìsà Oko fi máa ń ní àwon kan láàrín won tí wón jé wolé wòde àwon òrìsà won. Àwon àwòrò tàbí abenugan nídìí òrìsà kòòkan ló níye. Wón tún ní isé pàtàkì tí won ń se ní àpapò àti ní òtòòtó, yálà nínú ètò bíbo tàbí ètò odún òrìsà won. Ní ìlú Ìmèko, márùn únún ni àwon tí a lè tókà sí pé won ń sin òrìsà yìí lójú méjèèjí. Isé won ní àpapò ni láti rí pé gbogbo ètùtù àti àwon ohun mìíràn bí i ebo rírú tó bá ye ni síse láti mú kí inú Ìyáńlá yó sí àwo omo ìlú ní ìgbà gbogbo júse. Àwon ni wón máa ń mójú tó gbogbo ayeye odún gèlèdé. Bí ó tilè jé pé gbogbo àwon olùsìn yìí ń sisé pò nínú gbogbo ètò bíbo àti sínsin òrìsà yìí, síbè síbè olúkúlùkù won ló ní isé tirè tí a ti yàn fún un láti se. Isé tí ayàn fún òkòòkan won ló fi ibi tí agbára rè dé hàn ní ìdí ètò gèlèdé. Òrò isé àwon olùsìn gèlèdé wá di “kì í jé ti baba àti omo kó mà ní ààlà.”

ORÚKO ÀWON ÀWÒRÒ GÈLÈDÉ

1. Ìyálásè

2. Babalásè

3. Olórò èfè

4. Ìwòlé

5. Baba Akunbè