Igbagbo Awon Yoruba
From Wikipedia
ADÉDOYIN, ABASS ADÉGÒKÈ
ÌGBÀGBÓ ÀWON YORÙBÁ
Ìgbàgbó ni ohun tí àwon ènìyàn ìletò kan gbà lati máa se nípa sínsin Olórun tàbí bíbo Òrìsà won lóòrèkóòre. Gbogbo ohun to ba selè nípasè sínsin tabi bíbo Olórun tàbí Òrìsà náà ni àwon ènìyàn náà yóò gbà gégé bi àyànmó won. Irú awon wònyí ni a n pe ni onígbàgbó. Iyen ni pe awon to gba Igbagbo gégé bi ohun kàn-ń-pá. Ki awon Oyinbó to ko esin àtòhúnrìnwá wá sí ilè àwa ènìyàn dúdú (African) ni ìgbàgbó ti wa láàrin awon Babańlá wa. Eleyìí maa n waye nípasè èsìn abòrìsà tí ó wópò ni ilè Áfíríkà. Gégé bí àpere ni ilè Nàìjíríà àwon Olùsin àti Olùbo àwon orìsà ní ìgbàgbó púpò nitori pe nípasè bíbo àwon òrìsà wonyi, òkè ìsòro won máa n di pètélè. Bí o tilè jé pe àwon miran rò pe awon Yorùbá kò mo Olorin nípa àìmo-kan-àimò-kàn won sùgbón bi a ba wo ìse àti àsà àwon Baba-ńlá wa a o mò pé yàtò sí pe wón mò pé Olórun ni oba ti tí ó ga jù, wón tilè gba pe kò si oba míràn léyìn rè ati pe olórun yìí tí won tun mò gégé bí olódùmarè ni Oba tí o ju gbogbo oba lo. Olórun fún rarè túmò sí Olú-orun, eyi ni eni to ni òrun. Bakan náà ni Olodumarè tumò si olódù-omo-àrè tíi se eni ńlá ti ó tobi ti ko si ni àfiwé. Awon Orúko tàbí oríkì miran ti a fun Olórun fi ye wa gbangba pe awon Yorùbá gbà pé Olórun wà. Fùn àpere Olúwa túmò sí ‘Ògá gbogbo wa’ ní itúmò eréfèé. Oríkì isalé yìí ti Yorùbá fun olórun yoo tan ìmólè si ohun ti a n so:-
Adani-waye. Elédàá, Asèdá,
Oba tíi pa Ojó ikú dà
Oba Àjíkí
Olówó-gbogbogbo-tíi-yo-‘mo rè l’ófìn
Òyígíyigì, Ò-pabi-dà, Sobidire
Oba-àìrí, Oba tí kìí sá,
Atérerekáyé
Ògbàgbà-tí-í-gba-ará àdúgbò
A-tóó-gba-ni lójó ibi
Ó dabi pe ìbèrù ti awon Yorùbá ni nínú Olórun yìí ni ó fún won ni ìgbàgbó tí wón ní nínú ikú ati àjínde. Ìbásepò wà láàrin àwon òrìsà tabi Òòsà ilè Yorùbá àti Olódùmarè. Igbagbo awon Yorùbá ni pe àwon Òòsà wònyí jé alágbàwí láarin won àti Olódùmarè. Won sì gbàgbó pe awon Òòsà wònyí ni won lè rán sí Olódùmarè yálà lati toro ohunkohun lówó re tàbí dúpé fún ohun tó se fún won. Èrò yìi han nínú òwe Yorùbá tó so pé “eni mojú owá la ń bè sówá, Olójú owá kan kò sí bí kose ayaba”. Nitori náà Òòsà wà ni ìpò alágbàwí láàrin àwon abòòsà àti Olódúmarè. Bi a ba si gbo ti awon Yorùbá ba so pe ori mi o tàbí Olojo-oni o, Olódúmarè ni won ń pe ni ori, èyí ti o dúró fún eleda ori àti olójo oni, èyí ti o dúró fún eni ti o ni Ojo oni. Awon Yorùbá ní igbagbo to fesèrinlè nipa ìsomolórúko, won gba pe àwon eni wo to ti ku lo tun padà si ayé fun apeere oruko bii ìyabò, Babatúndé, Babajídé, Enílolóbò ati béèbéè lo. Iru àwon orúko wònyí fi yeni pe awon to lo lo tún padà wá. Awon orúko àbíkú bíi Aríorí, Enìgbàkan, Rófìmí ati béè béè lo náà fi igbagbo won hàn, èyí fihàn pe orúko niro omo. Ìgbàgbó àwon Yorùbá nipa àjínde léyìn ikú tún jé ònà miran. Bi a ba ye bi a ti se ń sin òkú ni ilè Yorùbá wò, a o mò pé a gbà pé bí won bá tilè kú won yóò tún jí dìde. Won yóò lo si ilè ibòmíràn lati lo máa se ilé ayé lo ni, ìdí nìyí ti o fi ye pe bi ènìyàn bá kù won a ni ‘ó pa ojú dé tabi ó pa ipò dá’. Nítorí irú ìgbàgbó báyìí ní í máa mú kí a máa sin àwon erú mo òkú awon àgbàlagbà bí oba, Ológun àti bee bee lo láyé àtijó. Irú àwon erú wònyí ni wón gbà pé won yoo máa se ìrànwó fún eni ń lá yìí níbi kibi ti o ba tún jinde sí. Yàtò sí èyí bi òkú òfò ba ku, ti àwon ènìyàn si gba pe ejò lówó nínú, wón lè lo sí orí sàréè rè kí won si pèé ki o si jade lati fi enu ara re so ohun tí o fa sábàbí ikú oró ti o kú náà. Igbagbo pe ajinde wa léyìn iku ni o fa bíbo ti a n bo àwon eni wa ti o ti ku ti a si fi bee so won di Òrìsà àkúnlèbo. Bi a ba ye bíbo egúngún àti gèlèdé ní ilè kétu àti ègbádò wò fínnífínní a o ri pe èyí ń fi ìdí ìgbàgbó àwon baba ńlá wa lórí ikú àti àjíndè múlè ni. Won si gba pe irú awon eni wa bee tí wón jé akínkanjú ti won si ti pèhìndà béè lè jé alárinà láàrin àwa àti Olórun. Yorùbá bo won ni ‘òrò ti akúwárápá bá so ará òrin ló so ó’, kìí se awa Yorùbá nìkan ni a ni irú ìgbàgbó yìí ó dàbí pé gbogbo èsìn ni ó níi Jésù ni àwon onígbàgbó elésin Kírísítì so di alarina láàrin won àti Olórun won léyìn ti ó ti kú tan. Ìdí nìyí ti wón fi maa ń pè é ni Alágbàwí won. Awon elésìn mùsùlùmí gbà pé mòńmódù ni alárinà láàrin won àti Olorun. Awon ti ń sín Búdà gbà pé òun ni alárinà láàrin won àti Edédàá won. Awon Yorùbá máa pa lówe pe ‘ayé lójà òrun nílé’ Ìdí ní pé wón gbà pe bí ènìyàn ba di arúgbó tí o si lo ibi àgbà ń rè yoo lo sí òrun tààrà ni. Sùgbón tí ó bá je òkú òròjú ni yoo bo agò ti àkókó sílè, yoo si tun máa lo gbé ibòmíràn títí ojó tí ó dá yo fi pé. Àkúdàáyà tàbí akuhan ni awon Yorùbá maa n pe iru eni béè. Nítori náà bí a ba wo ìgbàgbó àwon Yorùbá ni àwòfín, a o rí pe wón gbà pé ojókan ń bò ti a ó pàdé lálákeji ati pe ibe ni ilé tí a o fàbò sí. Èyí ni pe bi o ti wù kí a pe láyé tó a o pe lórun jù béè lo. Won ní, ma fòrun yòmí gbogbo wa là ń lo. Bákan naa ni Yorùbá tun gba pe ìdájó ń be àti pe ìdènà orun ni Olúkúlùkù yoo ti jábò isé owó rè láyé. Idi niyi ti won fi maa n wi pe ‘ejó ń be l’órun à-wí-fowóbojú’. Gbogbo èyí ní ó tun fi ese ìgbàgbó àwon Baba nla wa nínú iku ati àjínde hàn. Bi a ba wo ìgbàgbó nipa èsìn ìbílè a o ri pe àwon Yorùbá kò kèrè rárá. Àwon Yorùbá ni ìgbàgbó sí àwon Òrìsà won láti ìbèrè pèpè kí àwon elésìn mùsùlùmí àti elésin kírísítì to dé sí ilè ènìyàn dúdú. Nípa ìgbàgbó won, Ohunkohun ti won ba si toro lówó òrìsà won ti won máa n bo lóòrè kóòrè ni wón máa ń rí gbà lowo òrìsà won. Irú awon òrìsà wònyí ni Obàtálá, òrúnmìlà, Èsù, Ògún, Sàngó, òrisà oko, Oya, Egúngún, Osun òrìsà ìbejì àti béè béè lo. Bí ó tilè jé pé òpò àwon òrìsà wònyí ni wón jé ènìyàn télè kí won tó di òrìsà àkúnlèbo bóyá nípase akíkanjú won tàbí ohun ti won ti gbé se lókè erùpè. Bíbo àti sínsìn àwon òrìsà wònyí máa ń jé mímó lópò ìgbà. Ìgbágbó awon Yorùbá sí awon òrìsà wònyí ni o fà á ti won fi ni òwò àti ìmótótó sí won. Won kìí rú òfin òrìsà béè ni won kìí hùwà àìto sí won. Bákan náà ni won kìí búra eke àti pé iró pípa kìí wáyé pelu ilè dídà. Wón gbà pé òrìsà kìí fi òrò se ègbé, bi òrò bá ti ri ni i so, fún àpeere ojú esè ni sàngó máa n dájó fun eni to ba búra eke. Òrun sì lèrò eni to ba dalè òrìsà tó sì búra èké. Ìmúra àti ètò awon elésì ìbílè ní ojúbo ń fi ìwà mímó tí ó pò hàn, fun apere aso funfun tí kò ní àbàwón ni a máa ń rí lára OlÓbàtálá, aso osùn tó mó ni ti elégùn Sàngó. Bakan náà ni gbogbo ohun jije won náà máa n jé mímó pèlú. Bi a ba wa fi awon nnkan wònyí we àwon èsìn kírísítì àti èsìn mùsùlùmí ti wón gba òde lásìkò yìí, a o ri pe won férè bára mu, ìyàtò tí ó wà níbè ni pé awon elésìn àjèjì ń pe awon nnkan òkè yìí ni òfin nígbà tí ti ìbílè ń pe tiwon ní èèwò. ‘Bòwò fún Baba àti ìyá re ti kirisiti naa ni Omo awo kò gbódò hùwà Òyájú tàbí àrífin sí ògá nibi èsìn ìbílè.
ÌWÉ ÌTÓKASÍ
Sùpò ìbíkúnlé (1970):- Ìwé ìjìnlè Yorùbá Apákejì, Ìbàdàn OUP.
Dáramólá ati Jéjé (1970) Awon Àsà àti Òrìsà ilè Yorùbá bá, Ibadan O U P.
Omosade J.A. (1996) Yorùbá Beliefs and Sacrificial Rites, USA Longman.
Owólabí, Olúnládé, Olábíntán ati Adérántí (1986) Ìjìnlè Èdè ati lítírésò Yorùbá. Iwe kejì. Ìbàdàn, Evans brothers.