Adeoye Bakare

From Wikipedia

Adeoye Bakare

ÌWÉ ÌTÀN ÀRÒSO YORÙBÁ ÀKÓKÓ

Bí a bá se àfiwé iwe ìtàn àròso Yorùbá pèlú àwon èka lítírésò yòókù bí i ewì, àti eré oníse, a óò rí ì pé sèsèdé ni séńtúrì tí o kojá yìí ni ó tó dé sí àwùjo wa ní ilè Yorùbá. Ìwé ìtàn àròso jé ìtàn ti a fi ìrírí àròjunlè, o gbón inu, íyè ikùn àti ojú inńgbe kalè. Ìtàn àròso kò gbódò jé ìmò ìtàn (History) ìtàn àgbóso. Ìtàn àdàko tàbí ìtàn kan sákálá tí a gbé jáde nínú ìwé ìléwó ké ke ré kan. ìwé ìtàn àròso gbódò jé èyí ti eyo òrò inú rè pot ó béè gee kí á tí lè pe ìwé kan in ìwé ìtàn àròso ó gbódò jé èyí ti a ko silè sínú ìwé kan sandiri kì í se ohun àfenuso. E.M. Forster (1949) so nípa ìwé ìtàn àròso pé eyo òrò inú rè gbódò pò tó egbèrún lónà àádóta (50, 000). Sterenson (1960) ní tirè so wí pé ìwé ìtàn àròso gbódó jé èyí ti eyo òrò inú rè tó egbèrún lónà àádórin (70,00). Bísí Ògúnsínà (1991) sàlàyé wí pé ìwé ìtàn àròso gbódò jé afihan ìgbésí ayé omo ènìyàn ni ìbámu pèlú ìrírí àwùjo kan pàtó ní àsìko tàbí sáà kan. ó tèsíjú pé ìtàn náà gbódò jé àtinúdá ànkòwé kan pàtó tí ó ní àfihàn ibùdó ìtàn, èdá inú ìtàn,. Ìsèlè àti ìmò eré ìjìnlè tí ó báyému. Tí a bá lo àwon abuda ti a ti ménubà wònyi gégé bi odiwon tí a lè lò láti tóka sí ìwe kan gégé bí ìwé ìtàn àròso Yorùbá àkókó jade sí àwùjo Yorubá? Ìwé ìtàn àkókó tí ó jád ni ìwé péròó Aesopu ti Arógbeínlò gbé jáde ni 1910. Njé a le pe èyí ni ìwé ìtàn àròso bi? Rárá. Ìdí ni pé ìwé tí ó jé ìmò ìtàn (History) ni ó jé. Ìwé yìí kò ni àwon àbùdá tí a ti fòrò lé lórí nínú àpílèko yìí ní pa ìwé ìtàn àròso. Àwon ìwé ìtàn miiran tí ó tún jáde ni ìwé ìtàn Ìbàdàn tí Akínyele ko ni 1911 àti ìwé ìtàn Èkó ti Lósí ko ni 1913. Tí a bá tún lo àwon àbùdá tí a mò mo ìwé ìtàn àròso gégé bí òdiwòn láti se àyèwò awón ìwé yìí, a óò ríi pé ìwé ìmò ìtàn (History) ni àwon ìwé yìí jé, won kìí se ìwé ìtàn àròs Yorùbá rárá. Yàtò sí èyí, A. K. Ajísafé gbé àwon ìwé ìtàn bíi Ènìyàn sòro, Aiye Àkánárà, Tant’olórun àti ìgbádin Aiye, jáde láàárin 1919 sí 1923. tí a bá tún lo àwon àbùdá tí a mò mo ìwé ìtàn àròso gégé bí odiwon láti se àtúnpalè àwon ìwé yìí, a óò ní pé wón kì í se ìwé ìwé ìtàn àròso, ìwé ìtàn lásán ni wón jé. Àwon eyo òrò inú won kò tó èyí tí a fi lè pé wón ni ìwé ìtàn àròso. Tí bá tún wo ìtàn ìgbèyìn Adún àti omo òrukan ti E.A Akintan gbé jáde nínú ìwé ìròyìn Elétí ofe laaarin 1926 si 1927 a óò ri i pé àwon náà kìí se ìwé ìtàn àròso. Ìdí rè ni pé a kò kó àwon ìtàn náà jo sínú ìwé kan sandi. Èyí jé òkan pàtàkì lára àwon àbùdá tí a fi n se òdiwòn ìwé ìtàn àròso. Ìgbà wo wá ni ìwé ìtàn àròso Yorùbá àkókó jáde si àwùjo wa ni ilè Yorùbá? Adébóyè Babalola (1971) tilè so pàtó ni tirè pé ni odún 1936 ti Fágúnwà gbé ìwé ògbójú ode nínú igbó irúnmòlè jáde ni ìwé ìtàn àròso Yorùbá àkókó jade sí àwùjo wa. Tí a bá lo àwon abuda tí ó ya ìwé ìtàn àròso soto sí àwon ìjòrí lítírésò tàbí àwon ìwé yòókù, a óò ríi pe ohun tí Adébóyè Babalola so yìí jìnà sí òótó púpò kí ó tó di 1938, ni I.B. Thomasi ti gbé ìtàn Emi sègilolá jáde nínú ìwé ìròyìn Akáde Èkó ní 1929. Nígbà ti o di odún 1930 ni ó se àkójo ìtàn náà sínú ìwé sandi kan tí ó sì pé àkole rè ni ìtàn Emi Sègilolá. Nígbà tí a lo àwon abuda tí ó ya ìwé ìtàn àròso sótò si awon ìwé mìíràn tàbí èka lítírésò yòókù gégé bí òdiwòn láti se àtúpalè ìwé yìí, a ríi pé ìwé ìtàn àròso ni o jé. Ìtàn Èmi Sègilolá jé ìtàn atinuda onkòwé tí ó fi se àfihàn ibùdó ìtàn tí í se àwùjo ìlú Èkó èdá inú ìtàn, ìsèlè àti ìmò eré ìjìnlè ti o báyému. Ìtàn èyí kìí se ìmò ìtàn (History). Kì í se ìtàn àgbòso, kìí se ìtàn àdìko, kìí sì se ìtàn kan sákálá lásán ti a gbé jáde nínú ìwé ìléwó kékeré kan. ìwé ìtàn yìí jé ìwé ìtàn eyo òrò inú rè tilè ju egbèrún ló àádóta lo. Nípa lílo òdiwòn yìí tíí se àwon àbùdá ti a fi ń dá ìwé ìtàn àròso mò yàtò sí àwon ìwé mìíràn tàbí ìsòrí àwon lírírésò yòókù, a lè so gbangba pé ní odún 1930 ni ìwé ìtàn àròso Yorùbá àkókó jáde sí àwùjo wa ní ilè Yorùbá. Ìwé ìtàn Emi Sègilolá si ni inú ìtàn àròso Yorùbá àkókó náà tí ó jáde sí àwùjo wa ni ilè Yorùbá. Ìwé ìtàn àròso yìí jáde saájú ìwé ògbójúode nínú igbó-ìrúnmolè. ti D.O. Fágúnwà gbé jáde ni Odún 1938. Èyí tilè wà ni ìbámu pèlú Bísí Ògunsínà (1991) tí ó so pé pèlú àtèjáde ìtàn Èmi Sègilolá ni 1930. ìwé ìtàn ní ilè Nàìjíríà.

ÌWÉ ÌTÓKASÍ

Hair, F.E. H. 1967: The Early Study of Nigerian Languages. Combridge University Press.

King, B. 1971: Introduction to Nigerian Literature: Evens Brothers Ltd. Lagos.

Ounsina, J.A. 1976: The Development of the Yorubá Novel. M.Phil. Thesis University of Ibadan.

Ounsina, J.A. 1987: The Sociology of the Yorùbá Novel. Doctoral Thesis University of Ìbàdàn.

Ounsina, J.A. 1991: Ìdìde àti Ìdàgbàsókè ìtàn àròso Yorùbá, University of Ilorin.

Watt, I. 1957: The rise of the Novel. Chatto and Windus, London.