Idagba Soke Yoruba

From Wikipedia

Idaggbasoke Yoruba

Olatúndé O. Olátúnji (1984), Ìdàgbàsokè Èkó Ìmò Ìjìnlè Yorùbá Ibadan: Estorise Nigeria Limited. Ojú-ìwé = 165.

ÒRÒ ÀKÓSO

Àwon ebi olóògbé Olóyè Joseph Foláhàn Odúnjo (1904-1980) ni ó se ìfilólè àkànsé idánilékòó tí à ń pè ni J.F. Odúnjo Memorial Lectures in ìrántí baba won, eni tí ó ti filè bora bi aso. Nígbà ayé rè, Olòyè Odúnjo jé Asiwájú ilè Ègbá, Lémo ti Ìbará, àti Olúwo ti Irowo ti ìlú Ìbàràpá. Olóògbé Odúnjo tún jé òkan lára àwon omo Ìjo Àgùdà díè ti Pápà Mímó fi Oyè ńlá ti Ìjo Gregory àti ti Lumumba Mímó dá lólá lórilè-èdè Nàìjíríà. Eléyìí nìkan kó, Olóògbé Olóyè Odúnjo jé ònkòwé – òun ló ko gbogbo ìwé Aláwìíyé, akéwi sàn-án sàn-án ni, eni tí ó fi ogbón àtinúdá àti ìmò rè ko ìwé eré-onítàn, eré-onise àti ìtàn-àròso aládùn ni pèlú. Òpitàn ìtàn àtenudénu àti èyí ti a ko sílè ní olóògbé Odúnjo; korinkorin ni, gbajúmò olùkó-àgbà ni. Ní àfikún, ògbóntagí alákòósó àti aláàtò ni Olóyè Odúnjo nínú ètò ìsèlú. Òkan ní í se nínú àwon àgbà májèéóbàjé ìlú àti orílè-èdè wa lápapò nígbà ayé rè.