Ise Ona Ara Opon Ifa
From Wikipedia
Ise Ona Ara Opon Ifa
OHUN TÍ ISÉ ONÀ ARA OPÓN IFÁ Ń SO1
Contents |
[edit] ÌFÁÁRÀ
Yorùbá bò, wón ní a-sáré-inú-èkan kà sá lásán, bí kò lé nnkan, nnkan ni ó ń lé e. Ó férè má sí opón Ifá kan tí kò ní isé onà lára. Isé onà kòòkan sì ni ó ní isé pàtàkì kan tí ń jé fún aráyé, pàápàá oníbèéèrè àti Babaláwo, bí ó tilè jé pé kò lè ya enu sòrò gégé bí ènìyàn. Isé tí ó sì ń jé yìí kò sàìyé àwon tí ń jé irú rè fún,. gégé bí Oyin Ògúnbà (1978:23) ti sàlàyé nígbà kan rí. Sùgbón òrò wo ni isé onà kòòkan ń so? Isé wo ni ó ń jé? N óò fi èyí bàn nínú àlàyè tí n óò se báyìí.
[edit] ÌRÍSÍ OPÓN IFÁ
Lápapò, Opón Ifá lè rí kìrìbìtì, kí ó yípo, tàbí kí ó ní igun mérin2 (Abímbólá, W; 1977:9). Bí ó bá se kìrìbìtì, ohun tí ń fi hàn nip é òkìrìbìtí ni gbogbo ayé; se ni ayé yípo. Bí ó bá sì ní igun mérin, ó tún ń fi “orígun mérèèrin ayé” hàn bákan náà ni, gégé bí Wándé Abímbólá (1975:19) ti so. Ohun tí ìrísí kìíní-kejì yìí ń so ni pé àsírí gbogbo ayé pátá porongodo ń be lówó Ifá; gbogbo àbáyé ni òún rí; kedere sì ni ó ń wo gbogbo ohun ìkòkò tí ó sá pa mó fún èdá ní abé òrun. Òun ni “Elérìí ìpín, Òpìtàn…Ifè” (Abímbólá, W; 1976: 4; 10, 115).
Léhìn náà wàyí, gbogbo ara opón Ifá ni ó gún; gbágungbàgun kankan kò sí níbè rárá. Isé tí èyí ń jé nip é Ifá nìkan, tí òrò òun fúnra rè gún gégé, ni ó lè tó òrò elòmìí ti ó wó gún bí onítòhún bá sá tò ó. Ifá sáà ni “Òkítíbìrí a-pa-ojó-ikú-dà” (Lucas, O; 1948:75).
Perese tí inú opón Ifá téjú pàápàá kò sàìní isé tí ń jé. Ó ń fi hàn pé Ifá a máa fi inú han oníbèéèrè. Kò ní kòlòkóló kankan nínú rárá. Béè sì ni kì í sé òrò kù bí yóò bá dá enikéni ní ìmòràn. Ìdí ni èyí tí a fi lè fi okàn tán an, tí a si i lè fi òrò tí ń dunni lo ó fún ìmòràn. Sé kò kúkú ni í tanni jé nítorí pé òun ni “A-kóni-lóràn-bí-ìyeka-eni” (Abímólá, W; 1969:16).
Opón Ifá kojú sóke ni; kì í dojú délè. Ó fi hàn pé gbogbo ìgbà ni ó wa lójúfò. Ifá kì í sùn rárá. Tojú-tìyé ni òun fi ń reran gégé bí àparò. Lójúlójú sì ní í wo eni tí bá ń sòrò fun. Sé òpùró ní í dojú bolè; pòn-ún sì là á sòrò, mo-ni-mo-ní là á seke; sàn-án là á rìn, ajé ní í múni pekoro. Èyí nìkan sì kó. Ifá tún ń so pé òun ń gbé ilé ayé mo ohun tí ń lo lórun sé. Bí okùn ile ayé bá fé já,. òun ní í tún un so. Ti òrun pàápáà, bí ó bá wà ní sepé, Olódùmarè kò sàìmò pé ìrànlówó tí òun se tí ó fir í béè kì í se kèréémí. Òun Ifá ni “Gbáyégbórun”. (Abímbólá, W; 1969:9).
Àwòrán onírúurú èdá ni ó tò geerègè yí opón Ifá ká. Èyí ń fi hàn pe iloé ayé kún fún orísìrísi èdá. Bí ènìyàn ti wà ni erano wà. Bí ati rí èdá tí ń gbé inú omi gégé bí eja ni a rí èyí tí ń gbé orí ilè gégé bí ewúré, tí a sì rí èyí tí ń fò kiri ní ojú òruin gégé bí eye. Bí a sì ti rí èdá rere ni a tún ti rí èdá búburú. Kódà, bí a bá rí orísI èdá kan, gégé bí eja, ní apá òtún opón b;í a bá rí orísi èdá kan, gégé bí eja, ní apá òtún opón Ifá, a óò tún rí orísi kan, náà ní apá òsì rè. Ohun tí èyí ń so sì ni pé méjì-méjì ni Olódùmarè dá nnkan ní ilé ayé. Ó dá won ní ìjora, gégé bí ó ti rí nínú èyà ara tí etí òtún jo ti òsì, tí ìyé eyelé òtún jo ti òsì, tí àgbébò fi gbogbo ara jo àparò, tàbí ní ìtakora gégé bí òsán ti yàtò sí òru, tí ìtumò tí eja ní sì yàtò sí ti akàn nínú ìgbàgbó àwon Yorùbá. Ní sókí, tibi-tire ni ilé ayé; eye kì í sì í fi apá kan fò. Ohun tí ó fà á níyí tí ó fi jé pé abala méjì ni Odù kòòkan, títí kan àmúlù Odù pàápàá, ní nínú Ese Ifá. Bí a sáà ti ń rí Èjì Ogbè àti Òbarà Méjì náà ni à ń rí Ogbèyèkú àti Ogbèbàrà. Eyelé so nínú Èjì Ogbè (Abímbólá, W; 1976: 206-207) pé: …
Èjèèjì ni mo gbè,
N ò gbenì kan soso mó
… Èjèèjì ni mo gbè …
Síbè bí ó ti wù kí gbogbo èdá tí ń be ní àgbáyé pè tó, ti pé wón pagbo rìbìtì yí Ifá ká, tí Òrúnmìlà wá wà ní àárín, fi hàn pé ipò pàtàkì tí ó ye “Obàrìsà”(Abímbólá, W; 1977:xi-xii) tí òun jé ni wón fi í sí. Enì kan kò sì bá a dù ú. A kì í bá yímíyímí du imí. Kàkà béè, se ni gbogbo won gbárùkù tì í gégé bí alákòóso won pàtàkì. Kódà, gbogbo èdá yòókù ní í wò ó fún ìrànlówó àti ààbò. Ògúndá Méjì (Abímbóla, W; 1968:102-103) ni akápò Ifá ti so pé: … Ifá, ràtà bò mí,
Ibí pò lóde … Nítorí náà àti eégún, àti Òòsà, àti ènìyàn, àti eranko – gbogbo won ni wón ní í se pèlú Ifá. Bí a bá sì rí àwòrán èyíkéyìí nínú won létí opón Ifá, kí á mò pé isé tí Ifá ń rán an ní í jé níbè. Sùgbón kí ni isé tí òkòòkan àwon èdá tí a yá ere won sí etí opón Ifá ń jé? Kí ni ohun tí ń so? N óò sàlàyé òkòòkan báyìí.
Èsù Àárín gbùngbùn tí yóò ti lè máa wo Babaláwo lójú kòrókòró báyìí ni àwòrán Èsù wà lára àwon àwòrán yòókù létí opón Ifá. Ipò tí ó ga jù lo ni èyí. Ó sì níbá tí ó fi rí béè. “Èsù ni aláse fún gbogbo àwon òrìsà…omo òdò Èsù ni gbogbo àwon ajogun” (Abímbólá, W; 1977:xxiii). Òun ló ń ti ènìyàn tí ó fi ń se àwon èdá wònyí (Bólájí Ìdòwú, 1962: 83) tí ìdààmú fi ń dé bá a tó béè tí yóò tún fi fúnra rè fa olùpónjú náà to Babaláwo lo láti wádìí ohun tí ń da òun láàmú (Awólàlú, J.O; 1979: 29). Òun kan náà sì ni ó wá jérìí sí ohun tí Babaláwo ń se báyìí. Njé Babaláwo yóò “se é bí wón ti ń se é kí ó lè bàa rí bí ti í rí”? Èsù fé mo àmòdájú èyí.
Fún gbogbo ìsapá rè, Èsù wà níbè láti gba “aárùún tirè…(nínú)… gbogbo ebo tí a bá rú” nítorí pé:
Èsù ní í gba ebo
Béè ni kò mo Ifá á dá
(Abímbóla, W; 1977:xxiii).
Bí ó bá sì ti mú tirè, òun kan náà ni yóò gbé ìyókù dé ibùdà.
Kí á sáà ti so pé bí kò sí ti Èsù, Ifá kì bá tí rí eni wá sebo. Bí kò sí sí ebo, gbogbo ìbo ni ebi ì bá máa pa ní àpaàsíwó. Nítorí náà, àjospò tí ń be láàárín Ifá àti Èsù ga ju kí á wá Èsù kù ní ibi tí Ifá bá wà. Bí ìgbín fà, ìkarawun ń tè lé e ni. Òrò ebo rírú kì í sáà ń se kèréémí nínú Ifá. Ení rúbo lÈsù ń gbè (Abímbólá W; 1977: xix). Eni tí ó sì “dá wòn-ín” (Yémitàn, O. & Ògúndélé, O. 1970:4) Ifá ní í ko àgbákò Láàlú. Kálukú a ní:
Èsù mó se mí,
Omo elòmíìn ni o se.
(Àjùwòn, Bádé, 1972:5).
[edit] EYINDÌE
Èyí ń fi hàn pé elegé gbáà ni Ifá dídá; kí àti Oníbèérèré àti Babaláwo sóra se. Eni òrò bá ti owó rè bó rélè nínú won ru igi oyin; àtapa sì ni!
Ó tún ń fi han oníbèéèrè bákan náà pé òrò tí ó mú wá kò sòro ó yanjú rárá, gégé bí eyindìe kò ti sòro ó fó; kìkì bí ó bá ti lè tè lé ìmòràn Ifá ni sá o! Kò mú towó rè wá kò lè gba towó eni.
[edit] EYELÉ
Eyelé ń so fún oníbèéèrè pé ire ń be lótùn-ún lósì fún oníbèéèrè láti kó lo ní òdò Babaláwo bí ó bá ti se ohun tí Ifá wí. Tòtún-tòsì kúkú ni eyelè fi í kó ire wálé.
Eyelé ń rán Babaláwo létí pé kí ó má se da Ifá gégé bí òun àti Èjì Ogbè ti mulè tí won kì í sì í da ara won. Nítorí náà, kí Babaláwo se ètó.
Eyelé ń se ojú fún àwon eye yòókù. Eye, pàápàá èhurù sì ni àmì àwon Eleye. Nítorí náà, Babaláwo níláti rántí àwon Eleye kí ó sì tù wón lójú. Bí béè kó, won yóò ti esè òsì bo ohun tí ń se.
[edit] EJA ÀTI EWÚRÉ
Ara oúnje Ifá ni eja àti ewúré í se. Ifá a máa gba:
Eku méjì olùwéré,
Eja méjì abìwègbàdà;
Ewúré méjì abàmúrederede;
Einlá méjì tó fìwo sòsùká;
Eye méjì abìfò ga-n-ga.
Ata tí ò síjú,
Obì tí ò làdò,
Otí abóda
(Abímbólá, W; 1977: xxiii)
lówó oníbèéèrè gégé bí èrù. Nítorí náà, eja àti ewúré ń sojú fún àwon yòókù ni. Wón sì ń so fún oníbèéèrè pé kí ó má fi ebo saló. Dípò béè kí ó wá oúnje sí enu ìbo. “Olúbòbòtiribò (ni) baba ebo” (Abímólá, W; 1976: 38-39). Bí enú bá je, ojú a tì. Ebo kéékèèké sí ní í gba aláìkú là.
Lónà kan, ejá dúró fún èrò pèsè nítorí pé ilé eja kì í gbóná, tútù là á bá ilé eja. Àmì ire jèbútú omo sì ni ó jé. Sùgbón lóna mìíràn, ó dúró fún “béè-kó”. Bí wón bá ní “eja ni”, ó túmò sí pé nnkan náà kò senuure nìyen. Ohun tí èyí wá ń fi hàn nip é eja ni òrò oníbèéèrè yóò jé bí ó bá
…pawo lékéé,
Ó pÈsu lólè,
Ó wòrun yàn-yàn-àn-yàn
Bi eni tí ò ní i kú mó dáyé,
Ó wá á kotí ògboin sebo…
(Abímólá; W; 1969 : 43)
Yàtò sí pé àwon Eleye ń lo ààyè ewúré fún isé ibi won, àwon Babaláwo a máa fi ìfun rè pèèsè fún àwon Eleye (Abímólá, W; 1969:86). Nítorí náà, ó wà ní etí opón Ifá gégé bí ohun ti Babaláwo fi ń tu àwon Eleye lójú kí ó bàa lè rí ojú rere won.
[edit] ÒPÈLÈ
Òpèlè ni ohun àsárémú tí Babaláwo fi ń dá Ifá dípo Ikin. Nítorí náà, a lè so pé òun ni ó ń rán Babaláwo létí pé Ifá ń wo ohun tí ń se kòrókòró; isé tí Ifá rán an sì ni kí ó jé láiku eyo kan.
Sùgbón bí a bá rántí pé ìgbàkígbà tí Babaláwo bá ti ń lo opón Ifá, kò lè se kí ó má lo ikin, a lè béèrè pé kí tún ni ìwúlo òpèlè nígbà tí ikin tí Òrúnmìlà fi dípò ara rè níjó kìíní ti wà? Ìdáhùn fún èyí kò lo dan-in. Bí gbogbo ohun tí ń sojú fún Ifá bá wà ní àrówótó Babaláwo báyìí, yóò jé ki òun pàápàá mò pé kò sí ibì kan tí ó pamó kúrò lójú Ifá nínú gbogbo ohun tí òun ń se. Àní ojú tí ó ń wo òun léèkan soso ju igba lo. Kí òun sóra se ni ó tó, tí ó tún ye.
[edit] OWÓ EYO
Ara ìbò tí Babaláwo ń lo ni owó eyo í se. Ó dúró fún “béè-ni”. Àwòrán rè ń fi han oníbèéèrè pé kò sí ohun tí yóò sòro ó tú fún Ifá nínú ìbéèrè rè. Ó nílátí fi okàn balè. Ifá yóò yanjú gbogbo ìsòro tí ń dà á láàmú. Bákan náà sì ni ó ń ki Babaláwo láyà pé kí ó má mikàn, Ifá yóò kó o ní èsì tí yóò fún oníbèéèrè.
Owó eyo dúró fún ohun tí à ń ná. Ó sì ń so fún oníbèérè pé kí ó má sahun rárá; níná ni kí ó ná owó rè: kí ó mééta ìténí, kí ó fi kééjì adìbò, kí ó má sì pábo rú. Arojú-owó kì í sòsó. Bí kò bá ti háwó, ire tójú owó ń rí náà ni tirè yóò rí.
[edit] AKÀN
Èyí ń fi han oníbèéèrè pé ire ni òrò tí ó bá wá yóò já sí kéhìn; tutu bá gbèdègbede tí à ń bó ilé alákàn ni ara yóò tù ú dandan. Àmó yóò kókó jé béè-ni sí ìmòràn Ifá, kí ó mú un sà lóògùn ná. Èhìn náà ni Ifá yóò so òrò rè di akàn, láìse eja.
[edit] ÌKADÌÍ
Kókó pàtàkì kan ni gbogbo àlàyé àtèhìnwá yìí kàn mo okàn eni. Òun ni pé èmí òkòòkan nínú àwon èdá tí àwòrán won hàn ketekete létí opón Ifá ni ó péjú pésè sí ibi tí Babaláwo ti ń dífá. Èyí fún Babaláwo ní ìgboyà pé gbogbo èdá ni ó wà léhìn òun nínú isé tí òun ń jé. Isé náà ì báà dára, ì báà sì burú, dandan ni kí òun jé e. Bí òun bá sì wá sèrú wàyí o, gbogbo àwon èdá wònyí ni yóò dá sèríà tí ó dógbin fún òun. Nípa béè, ètó ni ó tó kí òun se nítorí “igba ojú”tí ń wo òun.
Bákan náà ni wón tún ń mú okàn oníbèéèrè balè pé Babaláwo kò jé tan òun je nítorí àwon elérìí púpò tí wón jo ń wò wón. Béè si ni òrò tí òun bá wá kò lè pa gbogbo èdá wònyí lódà dépò tí òun kò fin í í rí ìdí rè. Àgbà méta kì í pe èkùlù tì. Léhìn náà èwè, oníbèéèrè yóò tún rí èdò fi lé orí òrònro bí ó bá rú ebo tí Ifá kà fún un. Yóò ti mò pé núsojú Òòsà, Eleye, Èèyàn àti eranko ni òun mú àse Ifá se. Ebo òun kò sì ní í sàìdà dandan níwòn bí
“Eégun Ayé
Èsìbá òrun
…
Irúnmalè Ojùkòtún
Igbamalè Ojùkòsì
(Fábùnmi, M.A; 1972: 3)
ti lówó sí i. Okàn rè a si bàlè gégé bi ti tòlótòló.
Sùgbón gbogbo èdè tí àwon àwòrán wònyí ti ń pé yìí, láìfohùn ni wón ń se é. Kò ye kí ó yà wá lénu nítorí pé:
Òwe ni Ifà ń pa
Òmòràn ní í mò;
Bí a bá wí pé “mò!”
Òmòràn a mò;
Nígbà tí a kò bá mò,
A ní kò se.
(Lucas, J.O. 1948:79).
[edit] ÀKÍYÈSÍ
1. Òmòwé Bádé Àjùwòn ni wón gún mi ní késé nínú kíláàsì YOR 617 láti se isé yìí. Mo sì se é tán, mo ná án hàn wón-òn-òn, wón tún nà mí lógo enu. Àmó Òmòwé Akínwùmí Ìsòlá gbà mí ní ìmòràn pé ó ye kí n wádìí nípa ojú tí àwon Babaláwo fi ń wo ohun tí isé òhún dá lé. Kò sáà ye kí n fá orí léhìn olórí.
Ni mo bá sá to Awo Babalolá Fátóògùn lo ní 17/5/84 (ní yàrá won, AFS Rm 206). Awó kó, Awó rò; ilè sì kún. Sùgbón mo sàkíyèsí pé àlàyé tí wón se lórí òkòòkan nínú àwon àwòrán (isé onà) etí Opón Ifá kò sé, béè ni kò ya ohun tí à ń lo ohun òhún fún. Gégé bí àpeere, Awó ní:
Eku, eja ni Òrúnmìlà fi ń sètùtù fún
Ikú àìlóríta
Ikú júujùu bí ikú emèrè
…
Ifá gbeku gbeja
Kó o fi sèròrí akápò
… Lójú tèmi, níwòn bí irú àlàyé báyìí kò ti bá
[edit] ÌTUMÒ
tí isé náà dá lé mu, kò ní í túmò sí pé mo ko okà Awo kéré ni n kò fi ìjiròrò tí a jo se kú isé yìí. Béè kó rárá; àgbedò! Kàdà béè, ìtumò tí ó je èmi lógún sùgbón tí àwon kò kó lé okàn ní tiwon ni ó pàdí títa irú àtapínsè béè. Àrùn tí ó se obo kò se igún; orí igún pá, ìdí òbó pá. Ìtumò tí àwon bá se ni mo gbàgbó pé ó ye kí n fi wéra pèlú èyí tí èmí se. Sùgbón nígbà tí won kò se béè yìí ńkó?
Àbá tí n óò wá dá ni pé enikéni ni ó lè pe Babaláwo yòówù kí ó rí tè lórí ìtumò tí mo se yìí. Bí ìmò titun kan bá sì fara hàn nínú irú ìfikùnlukùn béè, mo se tán àtigbó o. Kódà, bèlèjé ni mo té etí mi méjèèjì, sílè; àgbóyé sì ni isé tí n óò fi wón se. Síbè náà, àdáàdátán ni opé mi lódò Awo Fátóògùn. A óò máa rí baba bá o!.
2. Alàgbà Rowland Abíódún ni wón kó só nínú kíláàsì YOR 617 (4/4/84, AFS Rm 204) pé a rí Opón Ifá mìíràn tí ìrísí rè dà bí ìgbà tí a bá la Opón Ifá tí ó se kìrìbìtì sí méjí ogboogba. Mo gbó o lénu won, ó sì ń se mí ní hààhin. Ni mo bá fi í tó Awo Fátóògùn létí (ní 17/5/84) tí wón sì so pé onítòhún to súnà. Orísi Opón Ifá yìí ni Awó pè ní Onípìn-ín-jésù (oní-ìpín-ojó-osù). Síbè náà, ohun tí Opón Ifá onípìn-ín-jósù yìí ń se kò fi béè yàtò sí ti àwon méjì yòókù. Òun ni pé láti apá kan òkun títí fi dé ìlàjì òsà, gbogbo ohun tí ń selè kò sèhìn Ifá; ojú rè tó won pátá porongodo.
OLANIPEKUN OLURANKINSE.
[edit] ÀWON ÌWÉ TÍ MO YÈ WÒ
1. Abímbólá Wàndé (1968) Ìjìnlè Ohun Enu Ifá, Apá Kìíní. Glasgow: Collins.
2. Abímbólá Wàndé (1969) Ìjìnlè Ohun Enu Ifá, Apá Kejì. Glasgow: Collions.
3. Abímbólá Wàndé (1975) Sixteen Great Poems of Ifá. Zaria: UNESCO.
4. Abímbólá Wàndé (1976 Ifá: An Exposition of Ifá Literary Corpus. Oxford University Press.
5. Abímbólá Wàndé (1977) Àwon Ojú Odù Merèèrìndínlógún. Great Britain: Oxford University Press.
6. Àjùwòn, Bádé, (1972) Àdìtú Ìjìnlè ohùn Enu-Ifá, Apa kíini. Ìbàdàn: Onibon-Ojé Press.
7. Awólàbú, J.O. (1979) Yorùbá Beliefs And Sacrificial Rites. Great Britain: Longman.
8. Fábùnmi, M.A. (1972) Àyájó, Ìjìnlè Ohùn Ifè. Ibadàn: Onibon-Oje Press.
9. Ìdòwú, E.B. (1962) Olódùmarè, God In Yorùbá Belief. Great Britain: Longman Nigeria Limited.
10. Lucas, J.O.. (1948) The Religion of The Yorùbás. Great Britain: C.M.S. Bookshop.
11. Ògúnbà, Oyin (1978) “Traditional African Festival Drama” in (eds.) Ògúnbà, O. and Ìrèlé. A: Theatre In Africa. Ìbàdàn: Ìbádàn University Press.
12. Yémiítàn, O. (1970) Ojú Òsùpá, Apá Kejì. and Ògúndélé, O. Ìbàdàn: Oxford University Press.