Ta la Ri Bawi?

From Wikipedia

Ta la ri ba wi?

Dele Adegbemi

Adegbemi

Délé Adégbèmí (1990), Ta la rí báwí? Abéòkúta, Nigeria: Gbémi Sodipo Press Ltd. ISBN: 978-183-019-0.

Ìwé eré-oníse yìí wà fún ìgbádùn tomodé tàgbà tó bá nífèé sí èdè Yorùbá. Mo ko ó láti fi pàtàkì omo bíbí láàárín àwa Yorùbá hàn àti ewu tí ó wà nínú kí ènìyàn jéjèé kí ó má san an. Bákan náà, a kò ní sàì kà nípa onírúurú ojúlówó àsà àti ìse àwon Yorùbá nínú ìwé yìí. Àròso pátápátá ni eré-oníse yìí láti ìbèrè dé òpin. Gbogbo orúko tí ó wà nínú rè kì í se ti òkú tàbí ti àlààyè. Bí a bá rí eni tí ó jo tirè, jíjo ló jo, òun kó. Eré yá.