Suuru ninu orin Orlando Owoh ati Dan Maraya Jos
From Wikipedia
Sùúrù
Yorùbá bò, wón ní, sùúrù lè se òkuta jinná. Wón gbà pé onísùúrù ní fún wàrà kìnìhún. Paríparí rè ni pé èdá tó ní sùúrù, ohun gbogbo ló ní. Adéoyè (1982:84-86) so ìtàn Àbàtìàlàpà tí ó jé ìkà. Májèlé ni baba àgbà ìkà yìí fi ń pa àwon ará ìletò rè. Léyìn òpòlopò ìpàdé omo kékéré kan rí ìdí agbára rè. Omodé yìí sì fi idà ahun pa ahun. Adéoyè sàlàyé pé èmí sùúrù ní àwon ará ìletò fi rí èyìn àgbà ìkà yìí. Pàtàkì àlàyé wa ni pé sùúrù ni ó lè borí ìsòro. Ó se pàtàkì kí á rántí pé ó se é se kí á rí ohun tí sùúrù lè se tí agídí kò le se sùgbón a kò le rí ohun ti agídí lè se tí ipá sùúrù kò ká. Bí èéfín se jé àmì pàtàkì fún iná ni ìjà jíjà àti gbólóhùn asò jé àmì pàtàkì tí a fi ń mo eni tí kò ní sùúrù.
Orlando sòrò lori sùúrù pé;
Akánjú tulú orán
Ò bá jé na sùúrù si
Egbèje rè kò tó í se bè
Ìràwò kò lè bósùpá tayo
Orán jé orísi olú kan tí ó máa ń hù ní ilè Yorùbá. Olú yìí kéré púpò. Tín-in-rín tín-ín-rín báyìí ni ó máa ń rí ó yàtò sí olú ewè tàbí bèje tí ó tóbi dé ibi pé tí a bá tu mérin péré, ó tó se obè. Sùgbón bí olú orán se kéré tó, a máa dùn púpò kì í tèdin bí àwon olú ńlá ńlá tí a dárúko. Àfiwé tí Orlando se níbí ni pé bí eni se sùúrù tí ó tu olú orán se ń je adùn rè ni eni tí ó bá se sùúrù ní òrò ilé ayé yóò se je ìgbádùn ayé. Àkíyèsí kejì ni pé, ó fi olú orán wé àwon olú mìíràn béè náà ni ó fi ìràwò wé òsùpá. Ó gbà pé Olórun kò da gbogbo ènìyàn bákan náà nítorí Olórun tó dá ìràwò kéré ni ó dá òsùpá tí ó tóbi. Ó ro àwon tí won fé máa sáre nípa tirè ki wón má dààmú mó. Yorùbá gbà pé eni tí kò mo ibi tí egbé rè ti là, eré ni yóò sá kú. Nínú ìgbàgbó àwùjo Yorùbá kò ye ki èdá kànjú ju elédàá rè lo rárá.
Bí a bá wo àwùjo àwon Hausa bákan náà ni omo ń sorí. Pàtàkì ni òrò sùúrù jé nínú ìwà omolúwàbí. Òwe Hausa kan so pé ‘Hakuri shi ne maganin duniya’ òmírán ni ‘Hanya lafiya, a bi ta da shekara’. Òwe kíní túmò sí pé, ‘sùúrù ni oògùn ayé, òwe kejì sì ń gba ni ní ìyànjú pé ‘kò ye kí á kánjú lá obè gbígbóná’.
Àdíìtì (Hadith) kejìdínlógún ti An-Nawawi sòrò lórí ìbèrù Olórun àti fífí rere san búburú. Nínú ìtúpalè rè ti Lemu (1993:50) se, o sàlàyè pé sùúrù jé òkan pàtàkì nínú ohun ti Ànábì Mòńmódù fi fa àwon ènìyàn wo inú èsìn mùsùlùmí. Ahmed (2000) náà kin òrò Lemu (1993:50) yìí lèyìn.
Dan Maraya sòrò nípa sùúrù nígbà tí o korin ìdárò fún olóògbé
Haladu Farin Isoho báyìí pé;
Mahaifa sun shaida
Abokai sun shaida
Haka kowa ya shaida
Ya shuka abin kirki
Akwai hakuri a wajen Haladu
Sannan ko akwai da ‘a
Bay ya rainin kowa ko
(Àsomó IX, o.i. 248, ìlà 10-16).
(Obi rè jé elerii
Àwon òré rè jé elérìí
Gbogbo ènìyàn je elérìí
Pé ó gbèrò rere, ó sì se rere
Haldu ni suuru àti ìteríba
Ó nìwà rere
Kì í fojú tenbelu enikeni
Nínú àyolò orin yìí, Dan Maraya sàlàyé pé onísùúrù èdá ni Haladu je nígbà ayé rè. Isé rere àti ìwà rere rè kò paré. Èyí ni ó jé ki òkorin yìí toro orun rere fún un. Ní àwùjo Hausa, ìgbàgbó nínú èsìn mùsùlùmí rinlè púpò. Wón gbàgbó pé léyìn ikú, àjínde wà. Eni bá fi ìwà rere se isé rere yóò lo sí àlùjóńà nígbà tí eni bá fi ìwà búburú se isé búburú yóò lo sí inú iná.
Dan Maraya tún sòrò síwájú nípa suúrù pé;
Mai –gida da uwar-gida
In an yi fada dan annabi
Don Allah a bar saurin fita
To amma in an bibiya
Wata kila gidan da munafiakai
(Tokotìyàwó e jòwó
Tí ìjà bá wà
Nítorí Olórun, e má se yára bínú
Bóyá tí e bá se ìwádìí dáradára
Àwon agbótekusoféye kan wà ní agboolé)
(Àsomó 10b, o.i. 266-267, ìlà 12-16).
Nínú àyolò orin yìí , òkorin ń gbìyànjú láti fi yé wa pé sùúrù ni a fi ń soko obìnirin. Eni tí a bá ń so fún pé kí ó má se yára bínú. Ohun tí a ń so ni pé kí ó se sùúrú. Eni tí kò bá ní sùúrù kò le se ìwádìí òrò ó sì sòrò fún eni tí kò le se ìwádìí láti rí òkodoro òrò. Ó ye kí á máa rántí pé ohun a fi èlè mú kì í bàjé, ohun tí a ba fi agbára sòro mú, koko ní le.
Ní àwùjo Hausa, àkíyèsí fi hàn pé ògòòrò ènìyàn a tètè máa bínú. Kí á tó séjú péé elòmíràn á ti fa òbe yo. Béè náà ni òrò rí nínú ètò ìgbeyàwó won Ìyàwó tí a sìn terùterù lè ti di ilémosú léyìn osù méta pére. Àpeere ìyorísí inú fùfù yìí ni Dan Maraya rí tí ó fi so nínú orin rè pé kí èdá máa se sùúrù. Bí a bá wo àwùjo Yorùbá àti Hausa. Ààyè pàtàkì ni àwon méjèèjì fi òrò sùúrù sí gégé bí ìwà omolúwàbí. Àkíyèsí wa ni pé àìmúsùúrù ti dá òpò wàhálà sílè nínú àwùjo méjèèjì. Àlàyé tí a se lórí ìforísónpón òpò ìgbéyàwó ní àwùjo Hausa ti bá àwon àwùjo ìlú ńlá ńlá ilè Yorùbá bí Èkó àti Ìbàdàn mu. Itó ni òpò àwon omo Yorùbá fi ń mo ilé ìgbéyàwó won kí á tó séjú pé é ìrì á ti wó irú ilé béè.
Yàtò sí òrò ìgbéyàwó, òpò ni àìnísùúrù lórí òrò owó wíwà ti gbé dé ogbà èwòn, ogunlógò si ti lo sí òsun òsán gangan. Kò sí ìyàtò kan pàtàkì nínú – ìwà àwon awakò ìlú Èkó ati ìlú Kano, tí ó bá kan òrò sùúrù, ànìnísùúrù á sì fa sún keere fà keere okò ní ààrin ígboro. Irú àwon àkíyèsí wònyí ni àwon okorin méjèèjì se ti won fi gbìyànjú láti fi orin won pàrowà fún aráyé.