Ona Igba Gbe Ounje Pamo

From Wikipedia

Ona Igba Gbe Ounje Pamo

ADENIRAN ADEBAYO SAMMUEL

“Yorùbá bò wón ní bí oúnje bá ti kúrò nínú ìsé, ìsé ti bùse”. Èyí nip é oúnje se pàtàkì púpò fún ìdàgbàsókè omo ènìyàn.

Láwùjo Yorùbá, òpòlopo oúnje ló wà tí enu ń je fún àpeere: oúnje òkèlè bí i Ìyán, Èbà, Àmàlà, fúfú, Abbl. Sùgbón láàrin àwon oúnje Yorùbá yìí, wón ka iyán kún púpò ju àwon oúnje ìyókù lo, èyí tí won sì máa fi ń ki iyán báyìí pé

“Ìyán funfun lélé, Oba nínú Oúnje

Ìjòyè àtàtà láwùjo òkèlè

Òré ilá, Olóbè ègísí

Kò sí obè tí kò bá tan

gbègìrì nìkan ni èèwò rè Abbl

Òríkì yìí fib í iyán se jé pàtàbì nínú oúnjeYorùbá hàn wá. Awon Yorùbá a tún máa pa àsamò kan láti fi hàn wá bí iyán jíje se jé pàtàkì tó

“Iyán ni oúnje Okà ni Oògùn

K’énu má dilè nit i gúgúrú

Àírí rárá làá je èko.

Èyí fi hàn wá pé iyán ni Yorùbá kà kún oúnje pàtàkì, tí a bá fé se àlejò, tí a gbé iyán fún irú ènìyàn béè, èyí nip é a ka eni náà sí púpò.

Àwon or`’iìsírìsí ewébè ló wà láti fi je Iyán, bíi, Ègúsí, Èfó, Ìsápá Abbl.

Lára àwon ewébè yìí, n ó gbìyanjú láti ménu ba òkan, èyí ni ìsápá, Gbíngbìn ni wón ń gbin ìsápá, Ohun obe sì ní í se, lára àwon èfó ló wà, Obè ègúsí ni wón ń fi ìsápá se, a sì máa dùn láti fi je Iyán, Ìdí niyi ti won fi maa ń so pe, “Ìsápá toro móyán, Gbègìrì toro mókà”. Orísírìsí ònà ni Yorùbá ń gbà kó oúnje pamó fún ojó iwájú, Ònà kan ni kíkí jo sí inú àká, sùgbón nípa ti ìyán jije, tàbí iyán àjekù, Yorùbá ní ònà tí wón ń gbà sewón lójò fún ojó iwájú. Tí iyán bá sékù láti àná, kò wúlò fún jíje mó, sùgbón àwon Yorùbá a máa se é lójò tàbí ki won fi pamó fún oúnje ní ojó iwájú, èyí ni wón ń pè ní pápánlùpá.

Pápálùpá ni Iyán àjekù àtàná tí a se lójò pamó fún lílò o ojó iwájú

Tí a bá je iyán kù di ojó kejì, a ó fi owó gé iyán yìí tàbí dá a sí wéwé, a sì le lo Òbe, léyìn tí a bag é iyan yìí tán, ó wá di isé sísá sí inú Oòrùn kí o lè gbe dáadáa, fún ìtójú pamó.

Léyìn sísá sí inu Oòrùn, to bat i gbe dáadáa tán, a lè gbe pamó fún osù méjì tàbí Odún kan tàbí jùbé è lo. Ní ojó tí a ba fé fi Pápánlùpá yìí se oúnje, tí o bá je pé alé ni a fe fi se oúnje, a ó ti dà á sí inú omi láti òwúrò, kí o le rò láti se é je àti láti lè fo gbogbo ìdòtí tó wà nínú rè dànù. Léyìn èyí ni fífò mó pàtàpátà, gbogbo pàntí inúi rè ni a gbódò fò dànù, a sì gbódò yòó bí ení yo ìresì olókuta (rice) nítorí pé òkuta lè ti bó sínú rè nígbà tí à ń sáa.

Tí ó bá ti mó dáadáa tán, a ó gbé ìkòkò kaná, èyí ti wá yàtò sí gígún bí iyán. A ó wa fi ìdérí ìkòkò tàbí abó sínú ikokò yìí láti fi àyè sílè ki omit í a gbé kaná lè wà ní ìsàlè kòkò. A ó wá mú pápánlùpá yìí tí á ti pèsè sílè fún sísè, a ó dìí sínú òrá tàbí inú àpò arómiyò, Ooru omi gbígbóná tí a gbé kaná yìí ni yóò jé kó jiná tí yóò sì dùn-ún wò lojú fún oúnje ènìyàn pápánlùpá yìí bò gbódò pé lórí iná púpò.

Léyìn èyí ni kí a dún ata sí i fún jíje ní àyè òtò, a sì le ré awúro sí ata rè láti lè mú kí ó dùn yàtò, àwon míràn a máa se èwà sí pápánlùpá yìí nítorí pé yóò ti yíra padà, yóò wá fi ara jo ìresì. Tí ènìyàn bá n jè pápánlùpá yìí, bí ìresì ló rí lénu pàápàá tí ènìyàn bá fi èwà sí i.

Irú ounje yìí pápánlùpá wópò ni òkè ògùn, ìpínlè Òyó orílè èdè Nìájíríà (òkè-ògùn, Oyo State Nigeria). Àwon bí; Sakí, Ìbàràpá, Ìgbòhò, Ìràwò, Tedé, Ìgbétì Abb.

A ò ni rí ìyàn nílè yìí (Amin) Ní àsikò ìyàn tí kò sí oúnje, àwon Yorùbá a máa kí ara won pé;

“E kú Ògbelè yìí o Ìdáhùn O!

“E kú Ìyàn yìí o Ìdáhùn O!

“Olúwa kí o fi orí jìn wá o Ìdáhùn Amin O!

“Olúwà kí o fi orí jìn wá o Ìdáhùn À nbè E o

Béè náà ni eni tí o jehun lówó, wón a máa kí irú won báyìí pé;

“Mo bá yín ire o Ìdáhùn E je k’a dìjo je é o

Yóò gba ibi ire o, a dúpé o” Àmín o Gbogbo èyí fi hàn pé Yorùbá ka oúnje kún púpò “kí àgbàdo tó dáyé, kiní kan ni Adìye ń jé kí awon Gèésì tó de ní Yorùbá ti ní ònà tí à ń gbà kó nnkan pamó fún lílò ojó iwájú. Gbogbo èyí fi ogbón àti ìmò Yorùbá hàn nínú àsà.