Egbe Orun

From Wikipedia

J.G. Fágborún (1982), ‘Egbé-Òrun’, láti inú ‘Àyèwò Ohùn-òrìsà Egbé-òrun ní Ágbègbè Ifè’, Àpilèko fún Oyè Bíeè (B.A) ní Department of African Languages and Literatures, OAU, Ifè Nigeria, ojú-ìwé 1-17.

EGBÉ-ÒRUN

Contents

[edit] OHUN TÍ ÀWON ÒNKÒWÉ WÍ NÍ SÓKÍ

Ní ìbámu pèlú àgbékalè ìwádìí yìí, a le pín ohun tí àwon ònkòwé ko gbogbo lórí EGBÉRUN sí ònà méjì - òrò nípa àwon òrìsà olómoyoyo àti ohun tí won so lórí òrò Yorùbá nípa Egbérun.

Òpòlopò àwon ònkòwé lórí àsà Yorùbá ló ti fi èrò Yorùbá àti ígbàgbó won nípa Egbérun hàn. Jéjé àti Dáramólá gbà wí pé kò sí ìyàtò láàrin Egbérun, emèrè àti àbíkú.1 Bákan náà ni èrò yí àti ti R.C. Abraham rí.2

Gégé bí òrò Smith, àlàyé tó wà lórí èsìn kò le kúnná tó bí a kò bá ménu ba àyíká ibi tí a wà tórí òun ló bí èsìn.3 Ohunkóhun ló le jé àpere òrìsà bí ó bá sá ti le hùwà tó mú okàn ènìyàn wá rìrì nígbà kan rí. Òkánkán ibi tí ohun ìyanu bá ti selè báyìí náà ni a máa ń so di ilè mímó tàbí ohun tí a mò sí ojúbo òrìsà.4 Fún ìdí èyí, kò ye kí ó yà wá lénu láti rí Egbérun tó rò mó igi abàmì, odò, òkè/òkuta torí àkíyèsí àyíká eni fi hàn pé nnkan kan gbódò máa gbé inú won kí oba òkè tó le fi irú olá tó ga béè wò wón tó mú won ta egbé won yo.

Láti túbò jérìí gbe eléyìí, Ògínní gba òrò so láti enu “Bally Yerkovich” pé Ìjèsà gbà gbó pé ebora inú ìrókò máa ń wo àse funfun tí yó sì máa kiri ní ògbánjó.5 A rí akérémedè mìíràn ti kì í kóhùngbe léèrùn. Irú eléyìí gba àkíyèsí ló jé kí wón di ohun bíbo bí òòsà.

Àwon ònkòwé mìíràn gbà wí pé àwon àbàmì igi àti òpè wònyí jé ibùgbé àbíkú.6 Wón ní irú àwon àbàmì igi wònyí ti gbàbòdì. Frazer so pé èyí ló fà á tí àwon gbégilódò fi máa ń pèsè fún irú igi béè tí wón bá fé é gé won fún pákó lílà.7 Ellis àti gbogbo àwon ònkòwé tó gbà wí pé èmí àbíkú ń gbé inú igi, òkè àti adágún odò kò jayò pa, sùgbón ó ye kí ó yé won pé kì í se gbogbo omo tí ń gbé ibi wònyí ni omo burúkú, gégé bí ìwádìí yìí se fi hàn. Àìgbà pé omo rere wà lódò òrìsà olómoyoyo ni kò jé kí Ellis ó le so pé a le toro omo lówó òrìsà tí a mò sí olómoyoyo.8

Àlàyé Adéoyè pegedé díè nípa eléyìí.9 Òun gbà pé a le toro omo lówó òrìsà tó je mó igi òun òpè. Ó ní obìnrin tí Ìretè - Àáyá (àpapò Ògúndá kan àti Ìretè kan) bá yo sí gbódò lo be òkè kó le rí omo bí. Eni tí Ìretè méjì bá ye sí ìrókò ni yó lo bo. Òsun ni eni tí Èjìogbé bá yo sí yó bo. Ohun tí a rí gbá mú níbí ni pé àwon oníwò le so pé kí abiyamo lo bo òrìsà olómoyoyo kí ó lè rí omo bí.

Abímólá tóka sí Egbérun gégé bí òrìsà nígbà tó so pé Kóórì jé olórí Egbérun.10 Ó ní ènìyàn a máa bo Ëgbérun láti rí omo bí. Ilésanmí náà kín òrò yí léhìn torí ó ní ibi tí won kì í bá ti í bo Kóórì ni wón ti ń bo Egbé èwe, lára egbé èwe yìí máà ló so pé omo olómitútù wà, èyí tí Òsun jé Ìyálóde fún.11 Ìyen ni pé ipò Kóórì ni Egbérun wà. Bí a bá fi eléyìí wé òrò Abímbólá tó ní Kóórì ni òrìsà kokànlérúgba nílè Yorùbá, a jé pé òrìsà ni Egbérun náà; torí Kóórì ni olórí Egbérun.12

Fátúbí Verger náà sòrò nípa àbíkú àti Egbérun.13 Nínú òrò rè, ó ménu ba bí àbíkú se ń yan ìpín lórun àti bí omo aráyé se ń pa kádàrá won dà léèkòòkan. Ó ní ‘Ìyájánjásà’ni kì í jé kí àwon èwe dúró pé láyé. A ó tún sòrò nípa ìyá yìí níwájú. Orí ohun tí Verger gbó láti inú Ifá ló gbé isé rè lé. Ó se àkíyèsí pé bí àkókó tí àbíkú bá dá bá fi le yè késé, kò ní í kú mó, sùgbón sá àwon “Egbé ara Òrun” yé gba agbára tí àbíkú náà ń lò. Òun náà gbà wí pé àwon àbíkú a máa ti òrun wá á ba mó etídò tàbí èhìnkùlé bí wón bá ń wá egbé won tó wà láyé kiri. Ifá nìkan ni Verger gbà wí pé ó le fi ònà dídá-àbíkú-dúró hanni gégé bí ó se hàn nínú Odù “Òsé Omolú.” Ó ménu bá ìpèsè tàbí àpèje tí àwon ará Dàhòmì (Republic of Benin) máa ń se fún Egbérun àti òrìsà ìbejì láti tù wón lójú. Ohun tó so níbi kò yàtò sí ohun tí àwon Ìyálómo náà ń se nínú ètò òrìsà olómoyoyo lásìkò àjòdún Egbé.

[edit] ÀKÍYÈSÍ NÍPA OHUN TÍ ÀWON ÒNKÒWÉ

Kò sí eni tó rántí so pé Egbérun kárí gbogbo àwa èdá ayé nínú gbogbo àwon tí a ye isé won wò. Egbé-Òrun tó jé àbíkú tàbí emèrè nìkan ló je wón lógún.

Won kò pààlà tó yanjú sí ààrin àbíkú àti emèrè. Omo elégbé ni àwon méjèèjì, sùgbón òkàn yàtò sí èkejì. Fún àpeere, Jéjé àti Dárámólá gbà wí pé òkan náà ni àbíkú àti Egbé-Òrun. Wón so eléyìí ní ìbèrè àlàyé won, sùgbón nígbà tí wón dé ìparí àlàyé won, wón ní kì í se gbogbo àbíkú ni elérè omo. A gbà béè, sùgbón ó ye kí won sì gbà wí pé kì í se gbogbo emèrè náà ni àbíkú gégé bí a ó se rí i ni iwájú.14

Àwon ònkòwé kan kò tóka sí àjosepò tó wà láàárín omo tí a toro lówó òrìsà olómoyoyo àti Egbérun.

Adéoyè gbà wí pé a le toro omo lówó òrìsà, sùgbón ó ní kò sí àbíkú.15 Ó yà wá lénu pé Adéoye yí kan náà ló gbà pé omo elégbé wà. Ó ní bí Odù Ifá “Atè nínú Ìlosùn” bá jáde sí aboyún, elégbé ni omo tó máa bí.16 Sé òun kò mò wí pé bí a kò bá tu omo elégbé lójú dáadáa yó di àbíkú.

Abímbólá àti Ilésanmí nìkan ló so pé a le tu Egbérun lójú lódò òrìsà, pàápàá lódò Kóórì tó jé òrìsà àwon èwe. Àwon fi àjosepò yí hàn díè. Wón gbà wí pé a le bo òrìsà elémo-yoyo láti rí omo bí àti láti dádìí àbíkú. Ára ohun tí a fé topinpin nínú ìwádìí yìí nìyen.

[edit] OHUN TÍ IFÁ WÍ NÍPA EGBÉRUN LÉKÙÚN RÉRÉ

Bí a bá ń fé èrí pàtàkì nípa ìtàn ìgbà ìwásè lórí Egbérun, òdò Ifá ló ye kí a lo. Ìdí nip é gbogbo ohun tó selè láyé àti lórun ló sejú Òrúnmìlà “baba elésé-oyán.”

Ifá ni a gbó pé ó kókó pìtàn àwon Egbérun. Se òun ni “akéré-finú-sogbón òpìtàn-alè-Ifè.” Ìtàn tó pa nípa emèrè ló fa òkikì rè tó lo báyìí:

“Òdùdù tí í du orí elémèrè

Ó túm orí eni tí ò sun-àn se.”17

Láti dá àbíkú dúró tàbí láti du orí rere fún àwon emèrè tàbí elérè omo, àwon oko a máa fa aya won fún babaláwo láti tójú, bí wón bá ti lóyún. Wón ní ìgbekèlé pé nípa rírú ebo ìgbà gbogbo fún aboyún béè, àwon èmí emèrè kì yó le pa orí rere tí omo tuntun náà ń bá bò wá sí ayé dà sí burúkú. Eléyìí náà ni a pè ní díduorí emèrè.

Níbi tí Òrúnmìlà mo àsírí àwon Egbé-Òrun dé, ó pìtàn orísirísI nípa won. Gégé bí òrò Ifá, Egbé-Òrun náà wà gégé bí egbé ayé náà ni. Nínú gbogbo àwon òrìsà àti ebora tí ń be ní ayé yìí kò sí èyí tó jé pé ilé ayé ni ó ti sè, bí kò se pè òrun ni elédàá ti fi àbá rè ránsé kó tó dip é a dá nnkan òhún sí ayé. Eléyìí rí béè nípa ohun gbogbo tó fi kan òkè, odò, igi, ènìyàn àti eranko. Kì í se pé nígbà tí ayé wà láyé tán ni wón déédé selè. Òrun ni ohun gbogbo ti sè wá sí ayé.

Àwon Egbé-Òrun tí a ń wí yìí, bí ènìyàn kan bá ń bò wá sí ayé nínú egbé rè ni yóò ti dìde tí won yó ti yàn án wá sí ilé ayé. Gégé bí egbé ayé se rí yìí náà ni, sùgbón tiwon ní àse láàrin ara won àti lórí ara won ju egbé ayé lo, torí ìwà bó-bà-jé-à-tú-ká pò nínú egbé ayé. Àdéhùn tí àwon egbé-òrun bá se won kì í jé kí ó yè, bí o ti wù kú ó rí.

Enì kòòkan tó wà láyé ló ní enì kejì lórun. Bí èyí tó wà lórun bá se rere, dandan ni kí èyí tó wà láyé náà se rere, torí, wón ní bí a se ń se láyé náà ni wón ń se lórun.18 E gbó bí Ògúndá soríire se wí nípa àwon ¬bòròkìnní òrun.

“Ó ní ayé sí

Ayé ń relé

Ìgèsin-òrun parí esin dà

Wón n ròrun.

Agbébatárìn ni ó soko alágbe

A difá fún bòròkìnní ayé

A bù fún tòrun.

Bòròkìnní òrun

Kì í jé kí táyé ó té

Tó bá kù dèdè

Tí tayé é bá té

Ni wón yó bá ké sí àwon tòrun

Pé bòròkìnní òrun gbà mí

Tayá ń té lo.

Òun náà ni wón fi ń sorin ko pé:

Egbé e mó mò jé n té o

Ènìyàn rere kì í tó bòrò

Égbé e mó mò jé n té o

Ènìyàn rere kì í té bòrò.”19

Eléyìí fi hàn pé bí ènìyàn bá mo Egbérun rè í tù dáadáa won a máa ranni lówó láyé láti se àseyorí.

Orísirísi Egbé-òrun ni Ifá tóka sí. Egbé rere wà, béè náà ni a rí egbé burúkú. Omo tó bá ń lo tó ń bò ni won ń pè ní ÀBÍKÚ. Òun náà ni Ifá pè ní omo Olójú-méjì.20

Àwon náà ni Ifá pè ní olè-òrun.21 Emèrè tó ń yún àyúnbò òrun náà ni a n pè béè. Gégé bí olè, se ni wón ń wá kó erù lóde Ìsálayé lo bá àwon egbé won lórun.

Irú won le lo nísisiyìí kí ó tó di pé ìyá won lóyún mìíràn. Wón le gbé àwò kan náà wá, wón sì le pààrò àwò. Bí ó bá jé obìnrin ni ìrìn yí, ó le wá ni okùnrin ni àtúnwá ayé. Ó le se eléyìí títí yó fi so ìyá rè di “onígbá-kí-lò-ńtà.”

Gégé bí Odù Ifá ATÈNÍNÚ-ÌLOSÙN se wí; àwon Egbé-òrun náà ní olórí. Ifá náà so pé:

“Saworo jìngbìnnì

Ó di jìngbìnnì saworo

A dífá fún Ìyá-jánjásà

Tí í solorí egbé lóde Òrun.”22

Ìyá-Jánjásà ni olórí egbérun kan. Ìgbà tí àwon omo egbé rè tí ó bá ń bò láyé bá kóra jo, Ìyá-jánjásà yó bi kálukú léèrè ibi tí ó bá ń lo. Eni tí ń lo sí Ìko-àwúsí, yó wà á wí. Elòmíràn a ní òun ń lo sí Òdòdòmù-àwúsè; elòmíràn sí apá Ìwonràn (níbi ojúmo tí í mó wayé). Òmíràn a ní òun ń lo sí Meréntélú Mèsànkáríbà ní Ìbámu pèlú bí orílè ayé se jé.23 Won yó sì ti mo ibi tí wón ń lo; bí lódò Oba ni bí lódò aboríkùrá ni. Won yó dá gbére ìgbà tí wón yó padà. Elòmíràn lo dá odún méta, Elòmíràn, osù méfà, ó sì le jé odún kan péró. Won yé ti fi àmì sílè nípa ikú ti wón bá fé kí ó pa àwon bí àkókò bá tó torí aráyé le féé dènà.

Ohun tí wón fi jé olè ni pé gbogbo nnkan tí wón ti fi ń sèké won láti ojó yìí wa ni won máa sà jo sára.24 Kíkú tí wón bá kú báyìí, gbogbo ohun èlò wònyí ni yó padà dà bí won se wà télè nígbà tí emèrè bá dé Òrun Àbíkú. Wón kérù dé nìyen.

Òkan lára àwon Odù Ifá tó tóka sí àwon “olè-òrun” yìí àti bí aráyé se já won ní tànmóò ni ÒSE-MÒÓLÚ (Òsé kò morí olú).25 Ó wí pé:

“Odosápéyoró;

Àrònì sí làbà yoògùn

Bónìí ó se rí;

Òla kì í rí béè;

Ní í mú babaláwo dífá oroorún,

A dífá fÉníki

Tí ń fomi ojú sògbérè omo.

Odesápóyoró;

Àrònì sí làbà yoògùn.

Bónìí ó se rí

Òla kì í rí béè

Ní í mú babaláwo dífá oroorún

A dífá fún Mójùwón Eníki

Odesápóyoró;

Bónìí ó se rí

Òla kì í rí béè.

A dífá fÓdébíyìí

Ode Ilé Eníki.” 25

Ìlú kan ló ń jé ìlú Ìki. Òrìsà tí wón ń sìn níbè ní òrìsàálá ló ń jé Ìkí.26 Ìki yìí ló kókó joba ibè bí atelèdó.

Nígbà kan Oníki (oba ìlú Ìki) ló dífá wón so pé kí ó rúbo kí Mójùwón omo rè tó ń se àbíkú máa baà se àbíkú mó. Ó ti bí Mójùwón kú tó bí èèmefà rí kí ó tó gbúròó ebo yìí. Ó gbó rírú ebó ó rú.

Ode kan sì wà nílé oníki tí orúko rè ń jé Odébíyìí. Ojú rè ni Mójùwón ti máa ń kú. Ó di ojó kan ode yìí go dé àwon eran tó máa ń je ìje àfèèmójú. Ó di èèkan ló ń gbó wújé wújé; àfi gbàgàdà gbàà ilèkùn, gbàà! Ni àwon kan bá ń kí ara won ku àbò sí ìpàdé nínú igbó kìjikìji. Wón hó yee. Wéré wón ti teni. Eni tí àpótí tó sí ti fi jókòó. Wón gbé àga olórí won sí ààrin, kóówá ń bósí iwájú láti se ìpinnu. Ó kan Omojùwón; òun náà dá àkókò. Ó ní bí igi ìdáná àkókó ba ti jó tán ni òun ń padà bò.27 Kí won tó gbé òmíràn ti iná òun yé ti padà. Ó ní bí eléyìí bá tàsé terí àwon aráyé náà a máa dógbón kúókúó; won a ní àwon ń di ènìyàn lónà nnkan; ó ní bí òun bá ti ga kan àtérígbà28 ni kí wón wá mú òun. Ó ní bí eléyìí bá wá á tì, paríparí gbogbo rè nip é nígbà tí òun yó bá lo sí Ilé-oko ni kí won wá á mú òun. Ó ní lójó Ilé-oko kòla ni kí wón rán ejò láti wá á san òun je. Ó ní eléyìí kò ní tàbí-sùgbón nínú. Báyìí ni kálukú se ìlérí àti àdéhùn lórí májèmu ohun tó máa gbé ilé ayé se. Léhìn náà ìlèkùn tì padà. Wón padà sí ibi tí wón tí wá. Ojú Odébíyìí ni gbogbo rè se.

Ìrúbo ti Oníki se ni kò jé kí Egbérun mò wí pé ode kan wà lórí ègùn tó ń wo ìse àwon. Ode délé, ó so ohun tó rí fún Oníki. Se ó sì ni àkókò tí àbíkú máa ń bó sínú aboyún. Ó so fún oba pé lónìí s’la, obìnrin re yó bímo.

Àwon awo so fún won pé se ni kí wón fi ìtì ògèdè ti igi ìdáná. Bí igi bá jó tán, ìtì ògèdè kò le jó.

Bí ó se wí yìí náà ni wón se. Nígbà tí ó di pé igi yó jó tán ni àwon Égbérun ránse dé. Ni wón bá ń fi ìyèrè ké sí Mójùwón:

“Wón ń se Mójùwón o ò

Omo Eníki.

Emi ló se táwa ò rí o mó?

Ìwo Mójùwón

Omo Eníki

Emi lé se táwa ò rí o mó.”

Ní òun náà bá fi ìyèrè dáhùn.

“Ó ní n bá tètè wá o ò

Èyin egbé mi

Odébíyìí ni kò mò jé n wá mó

N bá mò tètè wá

Èyin egbé mi

Odébíyìí ni kò jé ń wá mó.”

Báyìí ni wón se tí wón padà séhìn. Wón lo jísé pé enì kan tí wón n pè ni Odébíyìí àbí nkan ní ó dabarú àbá rè.

Ó tún bù se gàdà, Oníki lo béèrè pé se omo yìí kò ní í kú. Àwon awo so fún un pé kí wón já òkánkán enu-ònà kan òkè àjà. Kí ó má sí à ń bèrè kí a tó wolé mó. Wón se béè.

Nígbà tí Mójùwón dàgbàdàgbà tó dé déédé kinní tí wón já yen ló bá bèrè sí í nàgà. A ní òun tilè férè ga kan kínní yìí. Se ènìyàn kà sì le ga ga ga kí orí rè kan ilé. Báyìí ni owó pálábá se tún se mógi.

Nígbà tó té ilé-oko í lo, wón dífá wí pé se omo yìí bá esè rere dé ilé-oko? Àwon awo so fún wón pé eni tó ń lo sí ilé-eko yìí eèrà kò gbódò mò, Aso oko òun èwù oko ni ó gbé dé ilé-oko. Dìgbàdìgbà ni wón gbé e dé ilé-oko torí kò fé ètò tí wón se yìí.

Gbogbo àdéhùn métèètà ló yè. Báyìí ni Omójùwón ko se kú mó. Oníki ni béè ni àwon awo òun wí.

“Ode Sápóyoró.

Àrònì sí làbà yoògùn.

Bónìí ó se rí,

Òla kì í rí béè;

Ní í mú babaláwo dífá, oroorún.

A fdífá fún Mójùwón,

Èyí tí ó se omo Eníki.

Odesápóyoró

Àrònì sí làbà yoògùn.

Bónìí se rí

Òla kì í rí béè,

A dífá fún Odébíyìí

Ode ilé Eníki

Njé Méjùwón omo Eníki

Emi ló se táwa ò rí o mó?

N bá tètè wá

Éyin egbé mi

Odébíyìí ni kò jé n wá mó.”25

Ifá yìí tóka sí irú ìlérí tí àwon emèrè máa ń se àti bí wón se ń mú ìlérí won se. Ifá dídá lóòrèkóòrè ló kó Oníki ye lórò ti àbíkú omo yìí. Ó hàn pé bí ohun tí emèrè yàn bá fi le tàsé kò le kú mó. A rí i pé léhìn tí obìnrin bá ti soyún tán ni àbíkú tó ó máa ń bó sínú won.

[edit] GBOGBO EGBÉRUN KÓ NI OLÈ-ÒRUN

Odù Ifá Ògúndá - soríire náà ló tún pàtàn oríire tí í se omo oba ÈWÍ ADÓ. Ojú omo ló n pón Oba Eléwìí nígbà náà tó fi lo dífá. Wón ní kí ó rúbo kó le baà bí oríire lómo.

Ògúndá soríire so pé:

“Alubàtá ní í fègbé wòlú

A dífá fún ÈWÌ Àgbádó

Omo Ayó-gbìrì-gbiri-ògùròńsékù

Wón ní kó rúbo

Kó le ba à bí oríire lómo.”29

Àsìkò yí náà ni Oríire náà ń múra láti wá sí ilé ayé. Òun náà to àwon awo Òrun lo, wón kì fún un pé:

“Igi-ganganran má gún mi lójú

Òkèèrè téfé ni wón ti í kèèwò rè

A dífá fún oríire,

Tí gbérù nikòlé ayé.

Wón ní tó bá délé ayé

Kó wálé olórò kó sò sí.”


Oríire gbó rírú ebo, ó rú. Ó so fún àwon Egbérun rè ohun tó fé é se yìí. Àwon kì í sòwó àbíkú. Ó ní òun ń lo sòwò láyé ni. Àwon egbé rè náà sì so pé àwon yó ràn án lówó.

Àwon méjìdínlógún ló wà nínú egbé yìí. Wón mú adìe òsòòró kòòkan pèlú egbeegbàá wón fi ta oríire lóre. Wón ni kó mú lára rè sanwó oníbodè kó lo fi ìyókù sòwò láyé. Ò gbó ohun tí àwon awo rè wí ló se kó wonú-obìnrin Eléwìí tó fi lóyún, torí wón ní kò gbódò dé sí ibi kan ìdákúdèé láyé.

Oríire dàgbà tán, ó sisé sisé kò rí èrè isé jé. Ajé kò su fún un kó. Ó tálákà ju èkúté sóòsì. Bó se èyí, a di jábúté, bó se tòhún, ijábúté. Enu bèrè sí í ya àwon ènìyàn. Àsà nígbà tó ń bò tó gba adìe métàdínlógún àti egbàá métàdínlógún, wón ti bá a se àdéhùn pé bí ó bá dára fún un láyé, kó má se méní, kó má se méjì, kó sì fi ohun ìní kóówà ránsé sí i. Gbogb nnkan wònyí ni wón dì sínú ara oríire gégé bíi dúkìá.30 Oríire dáyé ó fowó rogi ìgbàgbé. Kò mo ohun tó yàn lórun mó. Isé oríire kò ní àkójo torí kò mú ìlérí egbérun rè se. Ara ìlérí rè ni pé bí ayé kò bá dùn, wéré ni òun yó padà, sùgbón àwon Egbérun kò rí Òdúlàdé, won kò rí Eégún.31 Fún ìdí èyí, okùn ayé Oríire tí wón so, won kò tú u sílè.

Bí Oríire bá lo sí oko-awo wón le so pé kí ó rú ewúré tàbí eyelé, awó tàbí etù. Owó tí won yó sì so pé kí ó fi lé e, le jé òké kan dípò iye tó je egbérun rè.

Ìgbà tó yá, àwon awo tó kì fún Eléwìí kí a tó bí Oríire tún wá á kì fún un. Wón ní kí ó lo rèé wá adìe metádìnlógún tó mo ní ìwòn àsésìn pèlú egbàá métàdínlógún. Wón kó gbogbo rè sínú àgè, ó di etídò. Ebo àrúdà tí wón pè, ó ti pé àwon Egbérun jo. Wón gbé ebo lo lójú won.32

Gbogbo nnkan tí Oríire se lófò, àsé òdò àwon Egbérun rè ló ń rogún sí; láti san èsan fún Oríire, wón gbé àpò àgbìrà tí wón ń gbágún ire tó ye kí ó jé ti Oríire wá sí ilé rè. Lásìkò yí náà ni àwon awo ní kí Oríire dá àpò àgbìrà kan kí ó máa so owó sínú rè kí ajé le mó on lówó33. Wón bá a da ìyèròsùn díè sínú rè. Wón ní kí ó máa fi irú owó béè ba enu kí ó tó fi sínú àpò tó gbé kó. Wón bá a sefá sí i lára.

Ká má pà á pírí, ìgbà yí padà sí rere fún Oríire.

“Báyìí ni Oríire bá ń jó

Ní ń yò.

Ó ní béè ni àwon babaláwo

Òun wí.

Álubàtá ní í fègbé wòlú

A dífá fún Èwí Àgbádó

Omo Ayó-gbìrìgbiri-ògùrò-ńsékù

Wón ní kó rúbo

Kó le baà bí Oríire lómo.

Ó réyelé ogún

Ó rágùntàn ogbòn.

Ó tu àtù-kelele kèsù.

Igi-ganganran má gún mi lójú.

Òkèèrè féfé ni wón ti í kèèwò rè.

A dífá fún Oríire

Tó ń tìkòlé òrun bò síkòlé ayé.

Wón ní tó bá délé ayé

Kó wálé olórò kó sò sí.

Ó délé ayé,

Ó wolé olórò ó sò sí.

Ajé mò wá ń se nímòrun àgbìrà