Akure
From Wikipedia
Akure
F.A. Ajakaye
Ìsèdálè ìlú Àkúré láti owó F.A. Àjàkáyé, DALL, OAU, Ifè, Nigeria
A kò le so pàtó odún tàbí àkókò tí won te ìlú Àkúré dó, sùgbón gégé bí Arífálò (1991) se wòye, ó ní Àkúré férè jé òkan lára àwon ìlú tí ó pé tí won ti tèdó ni ilè Yorùbá
Akure is probably lone of the oldest towns in Yorubaland.
(Arífálò 1991; o,1.2)
Ìtàn so fún wa pé, Aga, eni tí a tún wá mo orúko rò bí Alákùnré ni ó kókó te ìlú Àkúré dó. Orúkò bàbá rè ni ìyàngèdè. Ìtàn so fún wa pé, Èpé, ní èbá ìlú Òndó ni ó kókó fi se ibùgbé léyìn tí won kúrò ní Ilé-Ifè. Alákùnré tè síwójú láti dá ibùgbé tirè ní. Ní àsìkò yìí, ohun òsó owó rè tí á ń pè ní ‘Àkún’ gé. Ó pe ibè ní ‘Àkún ré’ nítorí ìtumò ‘gé’ ni ‘ré’ ní èdè Àkúré. Eléyìí ni ó wá di ‘Àkúré’ títí dòní yìí. Alákùnré sì jókòó gégé bí olórí ìlú. A kì í pè é ní oba ní àsìkò yen bí kò se ‘Omolójù’. Ó lo ipò rè bí olórí ìlú àti omo Odùduwà ní ìlú Àkúré.
Ní àsìkò yìí ni àwon omo Odùduwà ń je oba káàkiri ilè Yorùbá. A gbó pé, Àjàpadá Asodébòyèdé tí o jé òkan lára àwon omo Odùduwà kúrò ní ìlú Òsú, ó sì dúró sí ìlú kan tí won ń pè ní ‘Òyè’nítòsí Èfòn-Alààyè. Rògbòdìyàn, Ìsòro, ogun àti àìfokànbalè ko lu ìgbé – ayé Àjàpadá pèlú ara ìlú ‘Òyè’ náà. Ó wá di dandan fún Àjàpadá láti kúrò ní ìlú ‘Òyè’fún ààbò. Òun àti àwon alátìléyìn rè dórí ko ilè àìmòrí fún ibùgbé.
Àjàpadá gbáradì, ó kó àwon ènìyàn rè, ó sì se gégé bí akíkanjú àti ògbójú ode. wón rìn títí tí won fi dé igbó Àkúré, ibí ni wón ti bá won pa erin. Erin tí Àjàpadá pa fún àwon ará ìlú Àkúré fún àwon aré ìlú ní ìwúrí àti ìbèrù, nítorí pé, ode tí ó bá pa erin jé ode abàmì àti akíkanjú ode. Àwon ará ìlú Àkúré wá gba Àjàpadà gégé bí akíkanjú ode tí yóò lè ní agbára láti gba ará ìlú rè ní ojó mìíràn tí ogun tàbí òtè bá dé. Àwon ará ìlú Àkúré fún Àjàpadá ní orúko ‘Asodebóyèdé’.
Àjàpadá tí à ń pè ní Asodebóyèdé wá ní iyì gidi tí àwon ará ìlú sì féràn re gan-an. Àwon ará ìlú wá gbé Àjàpadá ga ju Alákùnré tí o kókó dé ìlú Àkúré lo. Alákùnré náà sàkíyèsí pé, àwon ará ìlú féràn Àjàpadá ju òun lo, ó wa dàbí eni pé wón rí ‘okó tuntun gbé àlòkù èsí dànù’. Alákùnré wá já owó rè nínú irókèkè àti akitiyan láti jé oba fún ìlú Àkúré bí ó tilè jé pé òun gan-an ni eni kìíní tí ó kókó te ìlú Àkúré dó. Itàn so fún wa pé Alákùnré fi tòwòtòwò kúrò fún Àjàpadá Asodebóyèdé.
Àjàpadá Asodebóyèdé wá jé oba ìlú Àkúré kìíní, gbogbo ayé gbó, òrun sì mò. Iwádìí fi hàn wá pé, Àjàpadá yìí jé omo Ekùn, Ekùn sì jé omo Òdùduwà1. Òdùduwà tí ó jé bàba Ekùn ni ó tójú Àjàpadá dàgbà nítorí Ekùn tètè kú. Àjàpadé jé omo rere, ó sì féràn láti máa seré káàkiri ààfin Òdùduwà, àwon ènìyàn a sì máa pè é ní ‘Àjàpadá Omo Ekùn. A gbó pé Odùduwà fún Àjàpadá ní èwù oògùn kan tí won ń pè ní ‘Èwù Ogele’ tí Òduduwà fúnra rè fi ń se ode, nígbà tí Àjàpadá pinnu láti dá ibùgbé tirè ní.
1. Orísirísi èrò ni ó wà nípa orúko àti iye omo Òdùduwà. Wo: T. A. Ládélé a.y. Àkòjopò Iwádìí Ìjìnlè Àsà Yorùbá. Ibadan’, Macmillan Nigeria Publishers Ltd. 1986, o.i. 1-2. Ohun méjì ni ó mú kí Òdùduwà se èyí, èkínní ni ìwà akíkanjú tí Àjàpadá fi hàn nígbà tí o fi ‘Àjà’1 kékeré pa eku edá nínú ilé àìlujú nígbà èwè re. Èkejì ni ìfé tí Òdùduwà ní sí Ekùn tí ó jé bàbá fún Àjàpadá. Ekùn sì tètè kú, ‘Omórèmílékún’ ni Àjàpadá jé sí Odùduwà.
Èbùn èwù yìí nìkan kò té Àjàpadá lórùn, ó be Odùduwà fún àwon ohun orò míràn, èyí wá jé kí Òdùduwà tún rob í baba Àjàpadá ti jé, ó sì wo ilé lo, nígbà tí o máa jáde, ó jáde pèlú ewà iwà mímó rè gégé bí oba. Ó gbé adé kan lówó, ó súre fún Àjàpadá, ó sì so fún Àjàpadá pé, ‘mo fi adé yìí jì ó’ Mo fi adé jì ó, ni ó wá di ‘Déjì’tí o jé orúko oyè oba ìlú Àkúré, gégé bí eni tí Òdùduwà fi adé jì2. Adé yìí je ìtókasí pé omo oba ni Àjàpadá.
1. Ohun èlò ode ti won fi irin se ni o ń jé ‘Àjà’. Ibi náà ni orúko Àjàpadá tí súyo tí o túmò sí ‘A fi ajà pá edá (Àjàpadá)
2. Èyí tí ó túmò sí pé, mo fi adé yìí fún o láéláé.
Àjàpadá omo Ekùn Asodebóyèdé, Déjì kìíní ní ìlú Àkúré jé akínkanjú ògbójú ode ni gbogbo ìgbésì ayé rè. Gégé bí àkosílè Weir (1934)1 ogójì oba ni ó ti je ní ìlú Àkúré láti ìgbà tí ìtàn ti bèrè. Oba merìn sì ti je léyìn àkókò tí Weir se ìwádìí tirè. Àpapò oba tí ó ti je ní Àkúré jé mérìnlélógójì2. À rí igbó pé obìnrin méjì ni ó wà nínú won.3 Obìnrin kìínì ni Èyé – Aró ti ó je oba ní odún 1393 títí di odún 1419 A.D. Ohun tí o fà á tí oyè fi kan obìnrin yìí nip é, òun nìkan ni ifá re fo rere láàrin àwon tí won dárúko fún ifá re fo rere láàrin àwon tí won dárúko fún Ifá. Àwon Àkúré sì fé tè lé ohun tí Ifá so nítorí pé won ti fi òpòlopò oba je tí won kò pe lórí oyè. Ifá so pé obìnrin yìí yóò pé lórí oyè àti pé àsìkò rè yóò tuba tùse. Obìnrin kejì tí ó je oba ní Èyémohin, ó wà lórí oyè ni odún 1705 títí di odún 1735. A gbó pé nígbà tí won tún dá ifá ní àsìkò yìí, ifá kò mú omokùnrin omo-oba kookan, bí kò se omo-oba-bìnrin yìí. Eléyìí ni ó mú kí àwon ará Àkúré fi omo-oba-bìnrin yìí je oba.
1. Wo: N.A. C. Weir 1934 Akure District Intelligence Report. Filo 41, 30014 Nigerian National Archives Ìbàdàn.
2. Wo Àfikún ‘I’ fún orúko àwon oba tí ó ti je ní ìlú Àkúró.
Oba Adésidá Afúnbíowó ni a gbó pé, ó pé láyé jù gégé bí oba ìlú Àkúré. Ó lo bí ogóta odún láyé (1897 -1957.) Àkíyèsí: A ko isé yìí láti inú àpilèko fún Oyè Émè ti F.A Àjàkáyé
A.F Àjàkáyé (1998) ‘Ìlò Orin Láwùjo Àkúré Àpilèko fún Oyè Émeè, DALL, OAU, Ifè Nigeria. Àsamò
Èròngbà isé yìí ni láti se ìwádìí sí ohun tí àwon ará Àkúré máa ń lo orin fún ní àwùjo won. Ó jé ònà láti sèdámò àwon orin àwùjo Àkúré, láti sàlàyé ìsèse àwon orin won àti láti se àgbéyèwò àwon kókó tí orin máa ń dá lé.
Ìlò orin ní àwùjo Àkúré tí isé ìwádìí yìí dá lé ni èròngbà láti sí ònà titun sílè fún àtúpalè lítírésò lónà láti mú kí àwon orin wònyí yé ni dáradára. Ó tún jé ònà láti sí ònà titun sílè fún ìwádìí lórí lítírésò alohùn pàápàá ti àwùjo Àkúré tí ó jé pé isé ìwádìí kò ì tí pò lórí rè.
À se àkójo-èdè-fáyèwò láti odò àwon òkorin. Apohùn ìsènbáyé àti àwon abínà-ìmò. A se àdàko àwon orin tí a gbà jo, a sì se àgbéyewò àwon isé tí won ti wà nílè lórí orin ní àwon agbègbè mìíràn. A ka àwon ìwá tí owó wa tè ní agbègbè náà, a sì rí òkó tó wúlò fún wa lórí orí òrò tí isé wa yìí dá lé.
Isé ìwádìí yìí fi hàn pé àkójinlè orin nípa síse àtúpalè kókó ohun tí à ń lo orin fún pon dandan kí a tó le ní òye isé onà àti Ìtumò orin ní àpapò.
Ìsé yìí tún jé kí ń ní ìmò nípa ìtàn Ìsèdálè, èsìn àti ètò ìsèlú àwon ará Àkúré.
Isé yìí tún fi hàn pé èsìn ní o máa ń bí àwon orin èsìn ní àwùjo Àkúré àti pé àsà àti ìse àwùjo ni ó máa ń se okùnfà fún àwon orin aláìjomésìn.
Ojú Ìwé: Oókàn-dín-láàádóòsàn-án
Alámòjútó: Òmòwé A. Akínyemí.