Ilaje

From Wikipedia

Ilaje

S.M. Raji, Adeyemi College of Education, Ondo, Nigeria

ÌTÀN ÀWỌN ÌLÀJẸ ÀTI ORÍRUN WỌN

Gẹ́gẹ́ bí ìtàn ti sọ fún wa, nínú ìwé tí ọ̀jọ̀gbọ́n Àtàndá Williams kọ”Who are the Yorùbás?” pé láti ilé ifẹ̀ ni Ìlàjẹ ti wá, nígbà tí Ọbàtálá wà lórí oyè gẹ́gẹ́ bí ọba, ni àwọn ènìyàn kan jáde láti ilé ifẹ̀ tí “ÒRÚNMÁKIN” sì jẹ́ olórí wọn tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò sí apá gúúsù tí wọ́n sì tẹ̀dó sí etí òkun níbi tí a mọ̀ gẹ́gẹ́ bíi ilẹ̀ Ìlàjẹlónìí. Àwọn Ìlàjẹ yìí ni wọn tẹ̀dó sí etí òkun ní Ìpínlẹ̀ Ondo. Ìtàn mìíràn sọ fún wa wí pé wọ́n kúrò ní ilé ifẹ̀;òrúnmákin, Ògìso (èyí tí o di ọba ti ìlú Benin) àti Jòwìrí (èyí tí o di ọba ti ìlú Àjàgbà) jẹ́ ọmọ ìyá kan náà. Ìgbà tí wọn bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò láti ilé-ifẹ̀ tí wọ́n rìn rìn rìn tí wọ́n dé ibì kan tí a mọ̀ sí Ìdó ni Ìpínlẹ̀ Ẹdó ni Ògìso, tí ó jẹ́ ẹ̀gbọ́n wọn pátápátá dúró tí ó sì tẹ̀dó síbẹ̀ láti ibẹ̀ ni wọ́n tí kó lo sí òde-Ìbínní, níbi tí a mọ̀ sí Benin lónìí. Ìgbà yìí ni Ọ̀rúnmákin àti Jòwìrí sì tẹ̀ sí wájú nínú ìrìnàjò wọn. Nígbà tí Ọ̀rúnmákin dé bèbè òkun tí a mọ̀ sí Ugbó ni òun náà dúró pẹ̀lú àwọn ènìyàn tirẹ̀ tí ó sì tẹ̀dó síbẹ̀. Nígbà tí èyí tí ó jẹ́ àbúrò fún wọn tí a mọ̀ sí Jòwìrí rìn sí apá òkè díẹ̀ tí òun náà tẹ̀dó ní tirẹ̀ síbi tí a mọ̀ sí Àjàgbà (Ìkálẹ̀) lónìí. Ọ̀rúnmákin tí ó tẹ̀dó sí ìlú Ugbò ni ó jọba sí ìlú Ugbò gẹ́gẹ́ bí Olúgbò ti Ugbò kí ó tó di pé àwọn ìletò wọn ń pọ̀ si bíi Títíkan, Àhérì àti Màhún nígbà náà. ̀ ÀWỌN I ̀LÚ ÌLÀJẸ

A kò lè sọ pàtó lónìí wí pé ibi báyìí ni ilẹ̀ Ìlàjẹ dé nítorí pé àwọn Ìjọ́ Àrògbò àti àwọn Ìtsẹ̀kírì tí wọ́n ń gbé ní apá àríwá Ìlà oòrùn àti ìwọ̀ oòrùn ilẹ̀ Ìlàjẹ kò jẹ́ kí a lè mọ ịdíwọ̀n ilẹ̀ Ìlàjẹ ní pàtó. Àgbègbè wọn tó nǹkan bí òjìlélẹ́ẹ̀dẹ́gbẹ̀ta kìlómẹ́tà yíká Ìgún mẹ́rẹ̀rin ọgbọọgba nígbà tí Ìkálẹ̀ wà ní àríwá , ó bá Ìjọ́ Àrògbò àti àwọn Àpọ́ì pààlà ní àríwá Ìlà oòrùn. Nígbà Ìtsẹ̀kírì wà ní Ìlà oòrùn wọn. Ọ̀nà méjì pàtàkì ni a lè pín Ìlàjẹ sí. Àwọn ni Ugbò àti Màhún. Ugbò pín sí ọ̀nà mẹ́ta:

(i) Ugbò

(ii) Ètikàn

(iii) Àhérì

Àwọn olú ìlú mẹ́ta pàtàkì wọ̀nyí náà ní àwọn ìlú tí ó wà lábẹ́ẹ wọn bíi:

(i) Ugbò: Lára àwọn Ìlú tí ó wà lábẹ́ Ugbò ni Ugbòńlá, Ìdí-ọ̀gbá, Ebíjìmí, Òde- Ugbò ni olú ìlú wọn níbi tí Olúgbò jọba sí gẹ́gẹ́ bí Olúgbò ti Ugbò.

(ii) Ètìkàn: Lára àwọn ìlú tí ó wà lábẹ́ Ètìkàn ni Etígbó, òkè- Etígbó, Òróyo, Òbè -Ńlá. Ètìkàn ni olú ìlú àwọn wọ̀nyí tí Oníkàn ti Òde Ìtìkàn sì jẹ́ ọba wọn ní ìlú Ètìkàn.

(iii) Àhérì: Lára àwọn ìlú tí ó wà ní abẹ́ Àhérì ní Òde- Màlún, Àgéngè, Zíon-pẹ̀pẹ̀, Àpáta, Arárọ̀mí, Olísénta, Ìgbókọ̀dá, Gbábíjọ, orí-òkè Ìwà mímọ́, Ìlóró, Páyamí. Òde – Màlún ni olú ìlú wọn tí Àmàpetú sì jẹ́ ọba wọn níbẹ. Àkíyèsí tí a lè se nípa àwọn ìlú wọ̀nyí ni pé wọ́n wà létí òkun, atí ọ̀sà nígbà tí púpọ̀ nínú wọn wà lórí ilẹ̀. llẹ̀ funfun gbòò ni ilẹ̀ wọn nígbà tí ilẹ̀ àwọn ìlú kan sì jẹ́ pupa bíi Màhún –tẹ̀dó, igbégunrún abbl. Àwọn ìlú Ìlàjẹ tí ó wà lórí ilẹ̀ ní Màhún-tẹ̀dó, Igbógunrín, Igbólómi, Ìtèbú-Kúnmi, Ìtèbú-Manùwà, Ìtèbú-Ẹlẹ́rọ̀, àtíjẹ̀rẹ́, Àgéngè, Ùréré-Àrà, Abòlà, Igbóńlá, Máhún. Àwọn ìlú tó jẹ́ ti orí omi tàbí ti ẹrọ̀fọ̀ pọ̀ lọ́dọ̀ ti wọn. Àwọn bíi Orí Òkè-Ìwà-mímọ́, Ayétòrò, Òkè-Olúwa, Zíòn-pẹ̀pẹ̀.

ORÍKÌ ÀWỌN ÌLÀJẸ

Ìlàjẹ ògóòmóní, Agbénọkọ̀ ghẹwà

Ìlàjẹ òmùrò, Àwa ọna yíwà búlẹ́búlẹ́

Jógbòri má màà

Ìlàjẹ Ọ̀tàlẹ́gwá, Èyárò únrígho

Àwa ọma Malòkun, ọba omi jọ̀ba òkè

Àwa ọma bẹrípató yí làjẹ gwà

Egungunrẹ́n Egungunrẹ́n

Ìlàjẹ Àyémàfúge

ÀWA YÈÉ !!!

ÈTÒ ÌSÈJỌBA ÀWỌN ÌLÀJẸ

Ètò ìsèjọba àwọn Ìlà́jẹ ní ètò púpọ̀ bí a se rí ọba gẹ́gẹ́ bí olórí ìlú tí a rí àwọn ìjòyè, bẹ́ẹ̀ la rí àwọn ọ̀dọ́ tí a mọ̀ sí òtú.

Àgbékalẹ̀ wọn

     ọba


Àwọn ìjòyè

Dóósùn

Ẹ̀ghàrẹ

Òtú

ỌBA ÌLÀJẸ

Gẹ́gẹ́ bí a ti mọ̀ pé ọba ló ń ba lórí ohun gbogbo, ọba ni olórí ìlú tí àwọn ìjòyè tàbí àwọn ìlú sì ń péjú lọ́dọ̀ rẹ̀ láti jíròrò nípa ìlọsíwájú àti ìdàgbàsókè ìlú. Ọba ló ní àsẹ, ààfin rẹ sì ni àwọn olóyè sì tí máa ń se ìpàdé. Ohunkóhun tí wọ́n bá jíròrò lè lórí dandan ni kí ọba fi àsẹ si kí ó tó di síse. Ọba sì ni àkóso gbogbo ìlú wà lọ́wọ́ rẹ̀ láti lo gbogbo ọgbọ́n ìmọ̀, òye àti láti lo gbogbo agbára rẹ̀ láti rí wí pé ìlú tùbà-tùsẹ. Òun lo sì máa ń síwájú ètùtù síse tàbí àdúrà síse fún ìfọ̀kànbalẹ̀ àwọn ará ìlú. Àwọn ìjòyè ló dúró gẹ́gẹ́ bí ìríjú tàbí ajẹ́lẹ̀ fún ọba ní àdúgbò tàbí àgbègbè kọ̀ọ̀kan tí ó wà ní abẹ́ ìsàkóso rẹ̀. Àwọn ló dúró gẹ́gẹ́ bí ìgbìmọ̀ ìlú tí wọ́n máa ń bá ọba sèpàdé tàbí gba ọba ní ìmọ̀ràn lórí ètò òsèlú. Àwọn ìjòyè yí pín sí ọ̀nà méjì àkọ́kọ́ ni Dóósù tí a mọ̀ sí ìjámà ufẹ̀, (èyí nipé ìjámà-ifẹ̀). Àwọn yìí ni olóyè tí ó ga jùlo tí wọ́n sì jẹ́ àgbàlagbà, tí wọ́n máa ń fún ọba ní ìmọ̀ràn. Àwọn náà ni ó máa ń sọ ìtàn ìsẹ̀dálẹ̀ àti ìtàn àwọn ọba tí ó ti jẹ sáájú fún ọba nítorí pé àgbàlagbà ni wọ́n. Nínú wọn ni ati rí Ọjọmọ, Yàsẹ́rẹ́, Líjọ̀kà, Ológbòsẹ́rẹ́ àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Ẹ̀ghàrẹ, àwọn yìí jẹ́ ìjòyè tí ipò rẹ̀ kéré ju ti ìjámà lọ lábẹ́ àgbékalẹ̀ ìjọba wọn. Àwọn Ẹ̀ghàrẹ yìí náà ní ojúse tí wọn ní abẹ́ ètò ìsèlú. Orúkọ àwọn oyè tí wọn máa ń jẹ ni Lọ́mọ, Ọjọmọ, Ọ̀dọ̀fin, Aró, Bágbòmírè, Ólíhà. Òtú ni ẹgbẹ́ à́wọn ọ̀dọ́langba, àwọn géńdé tí ó kóra wọn jọ láti lè ran àwọn àgbà ìlú lọ́wọ́ nípa títún ìlú se. Gẹ́gẹ́ bí àwọn Yorùbá tí máa ń sọ wí pé “Àgbà ní ńsèlú, ọmọdé nií tún ilé se”. Isẹ́ tí ó bá jẹ mọ́ isẹ́ tí àwọn àgbàlagbà kò lè se ni àwọn ẹgbẹ́ ọ̀dọ́ tí a ń pè ní Òtú yìí máa ń se láti jẹ́ kí ó rorùn fún àwọn àgbàlagbà láti sisẹ́ bí i isẹ́ ká tún ìlú se, ká dábò bo ìlú atbbl. Àwọn Òtú yìí á tún máa parí ìjà láàárín ara wọn, èyí tí kò se é parí ló máa de ọ̀dọ̀ àwọn àgbàlagbà tàbí ìjòyè. Wọ́n tún máà ń kápá ìwà ìbàjẹ́ láàárín àwùjọ.

DÍẸ̀ NÍNÚ ÀWỌN ỌBA ÌLÀJẸ NÍ WỌ̀NYÍ

(i) Olúgbò ti ìlú Ugbò

(ii) Àmàpetu tí ìlú Màlún

(iii) Oníkàn tí ìlú Ètìkàn

(v) Máporárẹ̀ tí ìlú Àgérigè

(vi) Olú tí ìlú Ìgbọ́kọ̀dá.

ÌGBÀGBỌ́ ÀWỌN ÌLÀJẸ ÀWỌN ÒRÌSÀ ILẸ̀ ÌLÀJẸ Ní ilẹ̀ ìlàjẹ, wọ́n máa ń bọ àwọn òrìsà bíi Malòkun, Olúwẹri, Èsù Ọ̀dàrà, Ọbalúwayé Sàngó Olúkòso, àti Ayélála Ìgbòkokò. Malòkun àti Ayélála ni òrìsà tí wọ́n gbajúmọ̀ jùlọ láàárín àwọn òrìsà tí wọ́n máa n bọ. Àwọn òrìsà yìí sì ní agbára púpọ̀, wọ́n sì máa ń se ìdájọ́ lọ́nà tí ó tọ́, láì fi igbá kan bọ̀ kan nínú. Àwọn òrìsà yìí ò fẹ́rọ́; lórí òtítọ́ ni wọ́n sì se ìdájọ́ ti wọn. Wọ́n sì máa ń gbèjà olódodo. Púpọ̀ nínú àwọn òrìsà tí wọn máa ń bọ ní ilẹ̀ ìlàjẹ ni wọ́n ní ìgbàgbọ́ nínú rẹ̀ nípa títọrọ àwọn nǹkan tí wọ́n bá fẹ́ lọ́dọ̀ Ọlọ́run nípasẹ̀ àwọn òrìsà tí wọ́n sìn wọ̀nyí. Ìdánilójú sì wà fún wọn pé àwọn yóò rí àwọn nǹkan náà gbà àti wí pé àwọn ní ó máa ń gbé ẹ̀bẹ̀ àdúrà wọn lọ sọ́dọ̀ Olódùmarè. Sùgbọ́n láyé òde òní, Ẹ̀sìn àjèjì Kìrìstẹ́nì àti ti Mùsùlùmí tí gbalé gboko ní ìlú àwọn ìlàjẹ. Ìjọ Kérúbù àti Séráfù ni ó fẹsẹ̀ múlẹ̀ jùlọ; èyí rí bẹ́ẹ̀ nítorí olùdásílẹ̀ ìjọ Zíọ̀nì jẹ́ ọmọ bíbí ìlàjẹ (The Most Revd (Dr) Àtàríoyè) Ajígbadé ọmọ Ògúnsèyífúnmi (a.k.a Lẹ́nẹ) tí ìjọ náà sì jẹ́ ìtẹ́wọ́ gbà láàárín àwọn ènìyàn rẹ̀. Àwọn ìjọ míìràn tó ó tún wà ní ilẹ̀ ìlàjẹ ní: ìjọ Àgùdà tí a mọ̀ sí Kátólíìkì, Ìjọ Elétò, ìjọ Onítẹ̀bomi, Ìjọ Sẹ̀lẹ́, Ìjọ C.A.C, Anglican àti ìjọ Ẹlẹ́rìí Jèhófà. Àtíjẹ̀rẹ́ sì ní mọ́sálásí kan. Àwọn ènìyàn wọ̀n yìí ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run lọ́kàn púpọ̀ wọ́n sì ní ìgbàgbọ́ nínú rẹ̀ jọjọ, nínú ohunkóhun tí wọ́n bá ń se.

ÀWỌN ORIN ÌBÍLẸ̀ ÌLÀJẸ Orin Bírípo àti Àsíkò ni orin ìbílẹ̀ àwọn ìlàjẹ. Orin Bírípo àti Àsíkò yìí náà sì ní gbajúgbajà orin ìbílẹ̀ àwọn ìkálẹ̀ pàápàá. Nínú orin Bírípo ni ìtàn ìsẹ̀dálẹ̀ àti ìtàn àtayébáyé sọdọ sí. Èyí máa wáyé nígbà tí wọ́n bá sun Olúsẹ àti Òjègbé lára orin Bírípo ni wọ́n tí máa sun Olúse. Wọ́n sì máa ń fi Olúse yìí sọ̀tàn ìsẹ̀dálẹ̀, ìtàn àtayébáyé àti ìtàn ìpèrí wọn. Sùgbọ́n nínú ìjègbé sísun wọ́n ti máa ki orísìírísìí ẹsẹ̀ ifá, ìrírí ayé. Orísìí orin míìràn sì tún wà tí àwọn ìlàjẹ máa ń kọ nínú èyí tí ẹ̀sìn kìrìstẹ́nì mú wá òun ni wọ́n ń pè ni orin Àlóre. Àwọn orin ìbílẹ̀ wọn yìí máa ń wáyé níbi àríyá, ìkọ́mọ́jáde, ìgbe]yàwó, ìsílé, ayẹyẹ oyè jíjẹ. Lára ìlú tí wọ́n máa ń lù fún Bírípo ni a ti rí àgbà, ìyá ìlù, pátákà, sẹ̀kẹ̀rẹ̀, agogo. Tí àsíkò ni a ti rí Sàmbà, Agogo, Sẹ̀kẹ̀rẹ̀, Àtàrí- Àjànnàkú.

ISẸ́ TÍ ÀWỌN ÌLÀJẸ MÁA Ń SE. Isẹ́ ẹja pípa ni ó jẹ́ isẹ́ tí ó gbajú gbajà láàárín àwọn ìlàjẹ. Wọ́n máa ń pa ẹja nínú òkun, ọ̀sà àti àwọn àyàsí odò ńlá. Isẹ́ ẹja pípa yìí ní ó sì máa ń mówó wálé jùlọ fún àwọn ìlàjẹ. Wọ́n á máa wí pé “Ẹni tí kò bá mọ ìsirò kìí sòwò Efólo” Wọn máa ń ta ẹja tútù àti ẹja yíyan. Orísìí àwọn ẹja tí wọ́n máa ń pa ni Edé, ẹja Efólo, ẹja Ọsàn, Àkàbà, kéjì, Tókò, Òkódó, Abó, Olóròóró, Agbékútà, Fìàfìà àti bbl. Yàtọ̀ sí èyí wọ́n tún máa sisẹ́ otí pípọn bíi ògógóró tí a mọ̀ sí ọtí líle, wọn sì máa ń dá ẹmu ògùrọ̀ pẹ̀lú. Wọ́n a sì tún máa hun ẹní. Orísi ẹní mẹ́ta ni àwọn ìlàjẹ máa ń hun, ẹní Òòré, ẹní Òjìkò àti ẹní Àtí. Wọ́n tún máa ń yọ́ omi òkun, wọ́n á gbe kaná láti yọ iyọ̀ jáde. Díẹ̀ nínú wọn sì ń dáko, èyí ni lára àwọn tí ìlú wọn wà lórí ilẹ̀.

ERÉ ÌDÁRAYÁ TÍ WỌN MÁA Ń SE. Àwọn ìlàjẹ máa ń se àwọn eré ìdárayá lórísìírísi gẹ́gẹ́ bí ó tí wà káàkiri gbogbo ilẹ̀ Yorùbá yókù bíi Eré Ayò títa, Bojúbojú, Eré Olóbèlè èyí tí wọ́n máa ń se nígbà ọdún Malòkun. ODÚN ÌBÍLẸ̀ TÍ WỌ́N MÁA Ń SE NÍ ILẸ̀ ÌLÀJẸ Ọdún orísirísi ni wọ́n máa ń se ní ilẹ̀ ìlàjẹ ní onílùúsílùú. Sùgbọ́n èyí tí ó jẹ́ pàtàkì tí gbogbo ilẹ̀ ìlàjẹ máa ń se papọ̀ ni a mọ̀ sí “Odún Malòkun”. Ọdún Malòkun yìí ló máa ń wáyé ní ìgbà kan lọ́dún nínú èyí tí gbogbo àwọn ọmọ ìlàjẹ tí ó wà légbè yóò wálé fún ọdún yìí. Ọdún Malòkun máa ń lárinrin ní ilẹ̀ ìlàjẹ osù kẹ̀jọ ọdún ni wọ́n máa ń se é. Àwọn ènìyàn yóò mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀bùn wá fún Olúgbò. Orísirísi ẹ̀bùn ni ọba máa ń gbà, sùgbọ́n àwọn Òtú tí a mọ̀ sí Ọ̀dọ́langba, ẹja ńlá tí ó tóbi jùlọ tí wọ́n bá rí pa ni wọ́n máa ń fi n ta ọba wọn lọ́rẹ.

Ìwé Ìtọ́kasí

Atanda Williams (1980) Who are the Yorubas University Pres Limited, Ibadan

Curwen (1937) “Ilaje Intelligence Report”

Erejuwa M. Adeyemi (2000) The print of A Genocide Ilaje /Ijaw War, Mega Point Limited, Lagos