Ire-Ekiti
From Wikipedia
Ire-Ekiti
F.I. Ibitoye
F.I. Ibitoye (1981), ‘Ìlú Ìrè-Èkìtì’, láti inú ‘Òrìsà Ògún ní ìlú Ìrè-Èkìtì.’, Àpilèko fún Oyè Bíeè, DALL, OAU, Ifè, Nigeria, ojú-ìwé 1-3.
Ìrè-Èkìtì jé ìlú kan ní agbègbè àríwá Èkìtì ní ìpínlè Ondó; èyí tí ó jé òkan nínú àwon omo bíbí inú ìpínlè ìwò-oòrùn àtijó. Tí ènìyàn bá gba ojú títì olódà wo ìlú Ìrè, ó rí bi kìlómítà márùndínlógójì sí Ìkòlé-Èkìtì tí í se olú ìlú fún gbogbo agbègbè àríwá Èkìtì. Sùgbón ó fi díè lé ni ogóje kìlómítà láti Ilé-Ifè. Èyiini tí a bá gba ònà Adó-Èkìtì. Nígbà tí a bá gba ònà yìí, léhìn tí a dé Ìlúpéjú-Èkìtì ni a óò wá yà kúrò ní títí olódà sí apá òtún. Ònà apá òtún yen tí wón sèsè ń se ni a óò wá tò dé Ìrè-Èkìtì, kìlómítà márùn-ún ibi tí a ti máa yà jé sí ìlú Ìrè-Èkìtì.
Ara èyà ilè Yorùbá náà ní ilú Ìrè-Èkìtì wà. Àwon gan-an pàápàá sì tilè fi owó so àyà pé láti Ilé-Ifè ni àwon ti wá. Wón tún tenu mó o dáradára pé ibè ni àwon ti gbé adé oba won wa. Nítorí náà, títí di òní olónìí, Onírè ti Ìlù Ìre-Èkìtì jé ògbóntagi kan nínú àwon oba Aládé tí ó wà ní Èkìtì.
Gégé bí n óò ti se àlàyé ní orí kejì ìwé àpilèko yìí, “Oní-èrè” ni ìtàn so fún wa pé wón gé kúrú sí “Onírè” ti ìsìnyìí. Alàyé Samuel Johnson nínú The History of The Yoruba. sì ti fi yé wa pé nítorí orísìírísìí òkè tí ó yi gbogbo èyà Yorùbá tí à ń pe ní Èkìtì ká, ni a se ń pè wón béè. Nítorí náà, orúko àjùmo jé ní “Èkìtì”. Ìtàn sí tún fi yé mi pé ìlú kékeré kan tí ó ń jé “Igbó Ìrùn” ni àwon ará Ìrè-Èkìtì ti sí wá sí ibi tí wón wà báyìí; àìsàn kan ló sì lé won kúrò níbè. “Igbó Ìrùn” ti di igbó ní ìsinyìí, sùgbon apá àríwá Ìrè-Èkìtì ló wà. Mo fi èyí hàn nínú àwòrán ìlú náà.
Ìsesí àwon ará Ìrè-Èkìtì kò yàtò sí tí àwon ìlú Yorùbá yòókù, yálà nípa aso wíwò tàbí àsà mìíràn. Àrùn tí í sìí se Àbóyadé, gbogbo Oya níí se. Àwon náà kò kèrè nípa gbígba èsìn Òkèèrè móra nígbà tí gbogbo ilè Yorùbá mìíràn ń se èyí. Esìn Ìjo Páàdi àti ti Lárúbáwá ni a gbó pé wón gbárùkù mó jù. Síbèsíbè, wón sì ń ráyè gbó ti èsìn ìbílè Yorùbá, bí ó tilè jé pé ó ní àwon àdúgbò tí èyí múmú láyà won jù. Fún àpere, mo toka sí àwon àdúgbò tí won ti mò nípa Òrìsà Ògún dáadáa nínú àwòrán.
Èdè Èkìtì nì òdè Àdúgbò won. Nítorí náà, ìyàtò tí ó wà láàrin èdè Èkìtì àti ti Yorùbá káríayé náà ló wà ní tiwon. Fún àpeere won a máa pa àwon kóńsónàntì kan bíi ‘w’ je. Won a pe “owó,” ‘Òwírò’ “Àwòrò” ni “eó”, “òúrò”, “Àòrò”. Wón tún lè pa ‘h’ gan-an je; kí wón pe “Ahéré”ní “Aéré. Nítorí náà “Aéré eó” yóò dípò “Ahéré owó”
Nígbà mìíràn pàápàá, won a fi eyo òrò kan dípò òmíràn, fún àpeere:
ira yóò dípò ará
erú yóò dípò erú
èyé yóò dípò ìyá.
àbá yóò dípò bàbá
ijó yóò dípò ojó
Gégé bí a se mo, àwon náà tún máa ń fi fáwélì ‘u’ bèrè òrò. Fún àpeere:
Ulé dípò Ilé
Ùrè dípò Ìrè
Ufè dípò Ifè
Ukú dípò Ikú
Òpòlopò ònà ni èdè yìí fi yàtò si ti Yorùbá káríayé. Nítorí náà, mo kàn sì ń se àlàyé rè léréfèé ni, n óò tún máa ménu bá wón nígbà tí a bá ń se àtúpayá èdè orin Ògún. Òrò pò nínú ìwé kóbò ni.