Osanyin

From Wikipedia

Osanyin

Dele C. Orimoogunje

Délé. C. Orímóògùnjé (1986), ‘Òsanyìn’, láti inú Odún Òsanyìn ní Osùn-ún-Èkìtì.’, Àpilèko fún Oyè Bíeè, Department of African Languags and literatures, OAU, Ifè, Nigeria, ojúìwé 1-3.

Orísirísi ìtàn ló wà lórí bí Òsanyìn se wáyé, nínú ese ifá náà si ni gbogbo rè ti je jáde. Okan lára àwon abénà ìmò mi so pé odún keèédógbòn tí a bí Òrúnmilà ni òsanyìn tó to omi ayé wò. Ó ni Òsànyìn jé eni tó féràn láti máa sun eyìn je ni won se ń pè é ní Òsanyìnje tó túmò sí iní tó ń sun eyìn je. Ìtàn mìíràn tún pé obìnrin kan wà tó yàgàn, ó yàpáta, bí o se ń romo léyìn adìye ló ń bú pùrú sékùn, Obìnrin yìí féràn láti máa sepo pupa tà, gégé bí òwò tí òpòlopò obìnrin ń se láyé Òde òní. Obìnrin yìí ru eyìn sòrí lójó kan, ló bá pàdé Òrúnmìlà ni ibi tó ti ń ru eyìn. rè lo sí ekù. Bí Òrúnmìlà se fojú kàn án ló bá so fún un pé kí o fún òun léyìn, nítorí pé ebi ń pa òun. Obìnrin yìí fún Òrúnmìlà léyìn. Se òmòràn tí í moyún ìgbín nínú ìkarahun ni baba-kere-finú-sogbón, ó ní Obìnrin yìí kò ní mú osù náà je kó tó lóyún. Òrúnmìlà ni òun san án ni èsàn-eyìn tó fún òun. Nígbà tí Obìnrin yìí wá bímo, ló bá so orúko omo náà ní Esan-eyìn. Gégé bí a se mò pé se ni èdè máa ń yí padà díè díè, báyìí ni Esan-eyìn se se kèrèkèrè di Òsanyìn. Ìtàn tó tún so nípa àtiwáyé òsanyìn je jáde láti inú odù Òsé-oníwo1 tó lo báyìí:

Òsé awo won n’ílé Elérín.

Èfúùfù lègè awo ò ‘jámò.

A díà fún Elésìjé-Mogboòráyè

Akoni t’órí’ò gbodò fó.

A díá f’Òrúnnúmìlà,

Edú Olójà nínú ebora

Ní’jó tí wón ní ‘ò l’énì kankan

àá bá s’eré mó.

Òrò kan ló se bí òrò ní ìpàdé tí àwon Òkànlénú irúnmolè ń se ní ojo métàdínlógún métàdínlógún. Gbogbo àwon irúnmolè bèrè sí í fi Òrúnmìlà se yèyé pé kò ní ègbón níwájú, kò sì tún ní àbúrò léyìn. Yèyé tojó tí a ń wí yìí kò seé kó. Bí gbogbo àwon irúnmolè se sòrò kò-bá-kùn-gbé sí í nìyí, ni ìrònú bá dorí-àgbà kodò. Bí ó se kúrò ní àjo àwon irúnmolè lójó yìí, òdò àwon awòye ríye ilé rè ló gbà lo, pé kí won ye òun lówó kan ìbò wò nípa bóyá òun lè rí enìkan tí yóò jé Omoléyìn fún òun. Wón ni ebo lòrò Òrúnmìlà gbà. Ó ní èsí ebo, èsí èrù?2 Wón ní kó rú Ogbósànán eyìn, eku mésànán, Obì mésànán, Orógbó mésànán, àdó mésànán àti Òké Owó mésànán. Nígbà tí Òrúnmìlà kó nnkan òdò Òsé awo won nílé Elérín àti Efúùfù lègèlègè awoò ‘Jámò, won pa gbogbo nnkan ebo yìí. Wón te Odù Òsé-Oníwo lé e lórí, wón ró ìtàn sí i3 ló bá lo gbé e fún ìyá rè, pèlú àlàyé. Ni ìyá yìí bá se àlàyé pé ó ti ju ogún odún lo ti òun tí rí àsé4 gbèyìn, tí kò bá sí àsé báwo ni àtibímo se fé bó sí i, àbí a lè se òòsà lódò kí làbelàbe má mò, Òrúnmìlà ní kí ìyá yìí sáà máa lò ó. Kí Òsùpá kerin tó yo sí ìgbà tí a ń wí yìí, ìyá yìí ti lóyún. Bóyá, ó súnmó okùnrin, a kò mò nírorí pé Ifá kò so èyí. Bó bá tilè jé pé kó rí Okùnrin tí òrò rè fi dayò, kò ye kó jé kàyéfì fún eni tó bá ti gbó ìtàn ìbí Jésù. Omo tí yóò bá jé àsàmú, kékeré ní ti í senu sámú-sámú. Ti Òsanyin bùáyà, àsàmú, kékeré ní ti í senu sámú-sámú. Ti Òsanyìn bùáyà, kódà ó légba kan jòrin nítorí pé láti inú Oyún ló ti ń dá bírà. Ní ojó kan tí ìyá rè lo sí oko igi, bó se fesè ko ló bá ké yéè! Bí èyí se selè se ni Oyún inú Obìnrin yìí kì í ní pèlé. Se ni ìyá yìí sáré délé pé kí àwon awo gba òun. Wón ní eno ni òràn rè je mó àti pé abami omo tí Ajàlórun ń rán bò wá sì òde-ìsálayé ló wà nínú Obìnrin yìí. Wón ní kó rú Òbúko, ewúré, àgbò, àgùntàn, àkùko kan àti òké owó mérìndínlógún. Láti ìgbà yìí, ibi tí ìyá yìí bá féé lo ni oyún inú rè ń so fún un bí ibè yóò se rí. Lójó tí wón bí omo yìí, wón bá ewé kan ní owó rè, ewé yìí ní wón gbìn tó kárí ayé tí wón ń pè ní ewé-Òsanyìn. Láyé Ojóun, àwon babaláwo ló ń so omo ní orúko, wón a wo Odù tó yo nígbà tí wón lóyún rè àti àwon nnkan tí won fi orúbo ní àkókò náà, ìdí ni pé ilé àti ìgbà là á wò ká tó somo lórúko ní ilè Yorùbá. Èyí ni àwon babaláwo ojó òún fí so pé omo tó jé pé eyìn mésànán ni wón fi kébo rú kí won tó lóyún rè, kò ye kó lórúko mìíràn ju Èsán eyìn. Orúko yìí ló ń yí padà díèdíè tó di Òsànyìn. Òrúnmìlà kó Òsanyìn ní Odù Ifá; sùgbón kò fokàn sí i. bí Oògùn tó ti ní èbùn rè láti ìsálú òrun, sé nnkan tó wuni ló máa ń pò lólà eni. Ìmò Òsanyìn jinlè nípa Oògùn òun ganan ló kó Òrúnmìlà ni Oògùn. Bí ó tilè jé pé, Òsanyìn kò lè ki Odù Ifá tí Òrúnmìlà kó o, ó mo àmì tó dúró fún òkòòkan. Ìdí rèé tí àwon Onísègùn fi ń mo Odù Ifá bí won kò tilè lè kì í. Ìtàn inú ese Ifá yìí so pé nígbà tí Òrúnmìlà ń lo sóde lójó kan, ó ní kí Òsanyìn máa roko èyìnkùlé. Òsanyìn se àkíyèsí pé gbogbo àwon ewé yìí ló wúlò fún Oògùn, ló bá fi wón sílè. Nígbà tí Òrúnmìlà bi í pé kín ni kò jé ro ó, orin ní Òsanyìn fi dá a lóhùn pé:


Eyí l’ewé ajé,

Kínni n ó ro ó?

Òkururu, Òkèrèrè

Kínni n ó ro ò?

Èyí l’ewé aya,

Kínní n ó ro ò?

Òkururu, Òkèrèrè,

Kínni n ó ro ò?

Èyí l’ewé Omo,

Kínni n ó ro ò?

Òkururu, Òkèrèrè,

Kínni n ó ro ó?

Èyí l’ewé àìkú,

Kínni n ó ro ò?

Òkururu, Òkèrèrè,

Kínni n ó ro ò?

Bí Òsanyìn se fi ewé han Òrúnmìlà rèé, òun ló ni Oògùn ní ìkáwó. Ìdí nìyí tí àwon Onísègùn se ń júbà rè lórí Oògùn tí wón bá fé se Òsanyìn ‘Molè, ó dowó re K’ó o j’óògùn yìí jé bí iná.

K’ó gbà bí oòrùn.

Ìjé iná ni k’ó jé

K’ó má jé ìjé oòrùn.

Nítorí bíná bá sun’su l’óko

A á mú un je ni.


B’óòrùn bá sì sun’su l’óko

Se là á so ó nù.

Ní Òtù-Ifè ni Òsànyìn wà tó ti ń jáwé fún gbogbo omo adáríhunrun. Ìyá re ló kókó sòògùn fún, ó sì fi tipátipá gba èjéègùn5 lówó ìyá yìí, ni ìyá yìí bá so pé isé tí yóò máa se jeun ni Oògùn àti pé Oògùn kò ní jé fún eni tó bá kò láti san èjéègùn fún Òsanyìn. Láti ojó náà ni Òsanyìn ti so isé oògùn di àselà pàápàá fún àwon Omo-léyìn rè. Lóòótó, tí a bá wo àwon ìtàn métèèta yìí, a ó rí i wí pé ibì kan ni àwon ìtàn métèèta forí so nípa bí eyìn se ń jeyo nínú Òsanyìn. Ìtàn kínní so pé nítorí pé Okùnrin yìí féràn eyìn sísun-je ni won se ń pè é ni Òsun-eyìn-je. Nnkan tó ye ká bi ara wa ni pé kín ni orúko ti Okùnrin náà ń jé télè kó tó di pé wón fi ìwà tàbí ìse rè so o ní orúko. Ìtàn kejì fi yéni pé èsan oore tí ìyá Òsayìn se fún Òrúnmìlà nípa fífún un ní eyìn ni won se rí Òsanyìn bí, ìdí nìyí tí ìyá rè fi so ó ní Èsan-eyin. Ìtàn eléyìí múná dóko tó. Tí a bá sì wo ìtàn keta tó so pé nítorí pé won fi eyìn mésànán kébo rú kí won tó lóyún rè ni àwon babaláwo se so ó ní Esán-eyìn, tí orúko yìí sì yípadà di Òsanyìn, a ó rí i pé èyí náà múná dóko. Nínú ìtàn métèèta wònyí ti bèrè saájú kí a tó bí Òsanyìn, yàtò sí èyí tó bèrè ìtàn orúko rè léyìn ìbí rè, tí kò sì so orúko tí ó ń jé télè.

ATÚMO

1. Òsé-Oníwo : Òkan lára àwon àmúlù Odù ni, wón tún lè pè é Ní Òsé-Olóògùn tàbí Òsé-wínrín. Àmi tó dúró fún Odù yìí rèé: oo o oo oo o o o oo

2. Èsí ebo, èsí èrù? : Kín ni rírú ebo?

3. ró ìtàn Pe àyájó

4. àsé Nnkan osù obìnrin

5. Ejéègùn : Nnkan ti Onísègùn bá gbà lówó eni tí se oògùn fún.

6. Ogbè-atè : Òken lára àwon àmúlù Odù ni, Oríkì rè sì ni “aláhéré-Owo”