Iwe Itan-aroso Akoko
From Wikipedia
ÌWÉ ÌTÀN ÀRÒSO YORÙBÁ ÀKÓKÓ
Bí a bá se àfiwé iwe ìtàn àròso Yorùbá pèlú àwon èka lítírésò yòókù bí i ewì, àti eré oníse, a óò rí ì pé sèsèdé ni séńtúrì tí o kojá yìí ni ó tó dé sí àwùjo wa ní ilè Yorùbá. Ìwé ìtàn àròso jé ìtàn ti a fi ìrírí àròjunlè, o gbón inu, íyè ikùn àti ojú inńgbe kalè. Ìtàn àròso kò gbódò jé ìmò ìtàn (History) ìtàn àgbóso. Ìtàn àdàko tàbí ìtàn kan sákálá tí a gbé jáde nínú ìwé ìléwó ké ke ré kan. ìwé ìtàn àròso gbódò jé èyí ti eyo òrò inú rè pot ó béè gee kí á tí lè pe ìwé kan in ìwé ìtàn àròso ó gbódò jé èyí ti a ko silè sínú ìwé kan sandiri kì í se ohun àfenuso. E.M. Forster (1949) so nípa ìwé ìtàn àròso pé eyo òrò inú rè gbódò pò tó egbèrún lónà àádóta (50, 000). Sterenson (1960) ní tirè so wí pé ìwé ìtàn àròso gbódó jé èyí ti eyo òrò inú rè tó egbèrún lónà àádórin (70,00). Bísí Ògúnsínà (1991) sàlàyé wí pé ìwé ìtàn àròso gbódò jé afihan ìgbésí ayé omo ènìyàn ni ìbámu pèlú ìrírí àwùjo kan pàtó ní àsìko tàbí sáà kan. ó tèsíjú pé ìtàn náà gbódò jé àtinúdá ànkòwé kan pàtó tí ó ní àfihàn ibùdó ìtàn, èdá inú ìtàn,. Ìsèlè àti ìmò eré ìjìnlè tí ó báyému. Tí a bá lo àwon abuda ti a ti ménubà wònyi gégé bi odiwon tí a lè lò láti tóka sí ìwe kan gégé bí ìwé ìtàn àròso Yorùbá àkókó jade sí àwùjo Yorubá? Ìwé ìtàn àkókó tí ó jád ni ìwé péròó Aesopu ti Arógbeínlò gbé jáde ni 1910. Njé a le pe èyí ni ìwé ìtàn àròso bi? Rárá. Ìdí ni pé ìwé tí ó jé ìmò ìtàn (History) ni ó jé. Ìwé yìí kò ni àwon àbùdá tí a ti fòrò lé lórí nínú àpílèko yìí ní pa ìwé ìtàn àròso. Àwon ìwé ìtàn miiran tí ó tún jáde ni ìwé ìtàn Ìbàdàn tí Akínyele ko ni 1911 àti ìwé ìtàn Èkó ti Lósí ko ni 1913. Tí a bá tún lo àwon àbùdá tí a mò mo ìwé ìtàn àròso gégé bí òdiwòn láti se àyèwò awón ìwé yìí, a óò ríi pé ìwé ìmò ìtàn (History) ni àwon ìwé yìí jé, won kìí se ìwé ìtàn àròs Yorùbá rárá. Yàtò sí èyí, A. K. Ajísafé gbé àwon ìwé ìtàn bíi Ènìyàn sòro, Aiye Àkánárà, Tant’olórun àti ìgbádin Aiye, jáde láàárin 1919 sí 1923. tí a bá tún lo àwon àbùdá tí a mò mo ìwé ìtàn àròso gégé bí odiwon láti se àtúnpalè àwon ìwé yìí, a óò ní pé wón kì í se ìwé ìwé ìtàn àròso, ìwé ìtàn lásán ni wón jé. Àwon eyo òrò inú won kò tó èyí tí a fi lè pé wón ni ìwé ìtàn àròso. Tí bá tún wo ìtàn ìgbèyìn Adún àti omo òrukan ti E.A Akintan gbé jáde nínú ìwé ìròyìn Elétí ofe laaarin 1926 si 1927 a óò ri i pé àwon náà kìí se ìwé ìtàn àròso. Ìdí rè ni pé a kò kó àwon ìtàn náà jo sínú ìwé kan sandi. Èyí jé òkan pàtàkì lára àwon àbùdá tí a fi n se òdiwòn ìwé ìtàn àròso. Ìgbà wo wá ni ìwé ìtàn àròso Yorùbá àkókó jáde si àwùjo wa ni ilè Yorùbá? Adébóyè Babalola (1971) tilè so pàtó ni tirè pé ni odún 1936 ti Fágúnwà gbé ìwé ògbójú ode nínú igbó irúnmòlè jáde ni ìwé ìtàn àròso Yorùbá àkókó jade sí àwùjo wa. Tí a bá lo àwon abuda tí ó ya ìwé ìtàn àròso soto sí àwon ìjòrí lítírésò tàbí àwon ìwé yòókù, a óò ríi pe ohun tí Adébóyè Babalola so yìí jìnà sí òótó púpò kí ó tó di 1938, ni I.B. Thomasi ti gbé ìtàn Emi sègilolá jáde nínú ìwé ìròyìn Akáde Èkó ní 1929. Nígbà ti o di odún 1930 ni ó se àkójo ìtàn náà sínú ìwé sandi kan tí ó sì pé àkole rè ni ìtàn Emi Sègilolá. Nígbà tí a lo àwon abuda tí ó ya ìwé ìtàn àròso sótò si awon ìwé mìíràn tàbí èka lítírésò yòókù gégé bí òdiwòn láti se àtúpalè ìwé yìí, a ríi pé ìwé ìtàn àròso ni o jé. Ìtàn Èmi Sègilolá jé ìtàn atinuda onkòwé tí ó fi se àfihàn ibùdó ìtàn tí í se àwùjo ìlú Èkó èdá inú ìtàn, ìsèlè àti ìmò eré ìjìnlè ti o báyému. Ìtàn èyí kìí se ìmò ìtàn (History). Kì í se ìtàn àgbòso, kìí se ìtàn àdìko, kìí sì se ìtàn kan sákálá lásán ti a gbé jáde nínú ìwé ìléwó kékeré kan. ìwé ìtàn yìí jé ìwé ìtàn eyo òrò inú rè tilè ju egbèrún ló àádóta lo. Nípa lílo òdiwòn yìí tíí se àwon àbùdá ti a fi ń dá ìwé ìtàn àròso mò yàtò sí àwon ìwé mìíràn tàbí ìsòrí àwon lírírésò yòókù, a lè so gbangba pé ní odún 1930 ni ìwé ìtàn àròso Yorùbá àkókó jáde sí àwùjo wa ní ilè Yorùbá. Ìwé ìtàn Emi Sègilolá si ni inú ìtàn àròso Yorùbá àkókó náà tí ó jáde sí àwùjo wa ni ilè Yorùbá. Ìwé ìtàn àròso yìí jáde saájú ìwé ògbójúode nínú igbó-ìrúnmolè. ti D.O. Fágúnwà gbé jáde ni Odún 1938. Èyí tilè wà ni ìbámu pèlú Bísí Ògunsínà (1991) tí ó so pé pèlú àtèjáde ìtàn Èmi Sègilolá ni 1930. ìwé ìtàn ní ilè Nàìjíríà.
ÌWÉ ÌTÓKASÍ
Hair, F.E. H. 1967: The Early Study of Nigerian Languages. Combridge University Press.
King, B. 1971: Introduction to Nigerian Literature: Evens Brothers Ltd. Lagos.
Ounsina, J.A. 1976: The Development of the Yorubá Novel. M.Phil. Thesis University of Ibadan.
Ounsina, J.A. 1987: The Sociology of the Yorùbá Novel. Doctoral Thesis University of Ìbàdàn.
Ounsina, J.A. 1991: Ìdìde àti Ìdàgbàsókè ìtàn àròso Yorùbá, University of Ilorin.
Watt, I. 1957: The rise of the Novel. Chatto and Windus, London.