Idagba Soke Yoruba
From Wikipedia
Idaggbasoke Yoruba
Olatúndé O. Olátúnji (1984), Ìdàgbàsokè Èkó Ìmò Ìjìnlè Yorùbá Ibadan: Estorise Nigeria Limited. Ojú-ìwé = 165.
ÒRÒ ÀKÓSO
Àwon ebi olóògbé Olóyè Joseph Foláhàn Odúnjo (1904-1980) ni ó se ìfilólè àkànsé idánilékòó tí à ń pè ni J.F. Odúnjo Memorial Lectures in ìrántí baba won, eni tí ó ti filè bora bi aso. Nígbà ayé rè, Olòyè Odúnjo jé Asiwájú ilè Ègbá, Lémo ti Ìbará, àti Olúwo ti Irowo ti ìlú Ìbàràpá. Olóògbé Odúnjo tún jé òkan lára àwon omo Ìjo Àgùdà díè ti Pápà Mímó fi Oyè ńlá ti Ìjo Gregory àti ti Lumumba Mímó dá lólá lórilè-èdè Nàìjíríà. Eléyìí nìkan kó, Olóògbé Olóyè Odúnjo jé ònkòwé – òun ló ko gbogbo ìwé Aláwìíyé, akéwi sàn-án sàn-án ni, eni tí ó fi ogbón àtinúdá àti ìmò rè ko ìwé eré-onítàn, eré-onise àti ìtàn-àròso aládùn ni pèlú. Òpitàn ìtàn àtenudénu àti èyí ti a ko sílè ní olóògbé Odúnjo; korinkorin ni, gbajúmò olùkó-àgbà ni. Ní àfikún, ògbóntagí alákòósó àti aláàtò ni Olóyè Odúnjo nínú ètò ìsèlú. Òkan ní í se nínú àwon àgbà májèéóbàjé ìlú àti orílè-èdè wa lápapò nígbà ayé rè.