Kiko Yoruba bi Ede Akokunteni
From Wikipedia
kiko Yoruba bi ede Akokunteni
Egbé Akómolédè (2001) Kíkó Yorùbá Bí Èdè Àkókúnteni Ibadan; University Press Plc. ISBN 978 030 527 0
ORÒ ÀKÓSO
A fi ara balè ko òwó ìwé yìí ní ìbámu pèlú Kòríkúlóòmù tuntun tí Ilé-Isé Ìwádìí àti Ìdàgbàsókè Èkó ní Nàìjíríà (National Educational Research and Development Council) se fún kíkó èdè Yorùbá bí Èdè Àkókúnteni ní ilé-ekó sékóńdìrì kékeré ní Nàìjíríà. Sùgbón nígbà tí a pàjùbà òwó ìwé náà tán, ó hàn kedere pé won yóó tún wúlò fún àwon tí won nífèe sí kíkó èdè Yorùbá kún èdè tiwon, tí won kì í se akékòó ní ilé-èkó sékóńdìrì kékeré ní Nàìjíríà.
Lára àwon tí a rí pé yóò tún se béè wúlò fún ni: àwon akékòó ní ilé-èkó sèkóńdìrí àgbà ní Nàìjíríà tí won kò ní ànfààní Oníp kejì, kóléèjì Eń siì lì àti irúfé àwon akékòó béè ní Yunifásítì ní Nàìjíríà. Bákan náà ni òwó ìwé yìí tún wà fún àwon àgbà tó ti mò-ón-ko-mò-ón-kà ní èdè mìíràn ni Nàìjíríà tàbí ní orílè-èdè mìíràn ní àgbáyé, tí won nílò láti mo èdè Yorùbá múlò fún tí wón bá ń kó elédè mìíràn.
Àwon omo Egbé Akómolédè àti Àsà Yorùbá Nàìjíríà tí ó ní ànfààní láti lówó sí kíko òwó ìwé yìí dúpé gidigidi lówó Egbé náà fún yíyàn tí a yàn wón; wón sì dúpé lówó ilé-isé Asèwétà Universtiy Press PLC. Bákan náà, a kò le sàì dúpé lówó Olútùú èdè Yorùbá ilé-isé náà, Adéolá aya Fáléye fún akitiyan won lórí gbígbé òwó ìwé náà jáde lónà ó wú ènìyàn lórí.
Ibi tó bá kù sí, a ó máa sé àtúnse rè lójó iwájú ní agbára Olódùmarè, Eni kan soso tí isé owó Rè péye. Ní báyìí, a kè sí yín, ará ilé, èrò ònà, e bá wa fi òtító-inú àti ìfé pípé gba obè yìí; kí e tó o o wò; kí e sì so fún wa bí ó se rí lénu yín o.
Ire Kàndù!