Eko Ede Yoruba Alawiiye
From Wikipedia
Eko Ede Yoruba Alawiiye
J.F. Odunjo (1967), Eko Ijinle Yoruba Alawiye (Fun Awon ile Eko Giga; Ibadan, Caxton Press (West Africa) Limited
Ni òde òní, opolopo awon omo ile Yoruba ni nwon ti gba oyè giga fun ìmò ìjìnlè ti nwon ni nínú àwon ìlànà ìjìnle èkó lorísirísi. Awon miran gba oyè nínú èkó ìwòsàn ati òfin ìlera; nínú èkó ìsirò tàbí ìs;unná owó; èkó ìjìnlè nipa ìtàn ìlú; ati nínú èkó ìjìnlè pelu nínú Èdè Gèésì ati awon èdè Oyinbo miran síso ati kíko sile. Nítorináà, ko nsòro rara lati ri nínú àwon omo wa ti a lè yàn bi oluko fun kíkó àwon omo ile-èkó gíga ni èkó ìjìnlè nínú eyikeyi nínú irú àwon ohun wonyi. Sugbon nínú èkó ede Yorùbá ni o máa nsòro ni ìgbà pupo lati rí àwon omo Yorùbá ti o ni ìmò ìjìnlè to lati kó àwon akeko ile-èkó gíga ni èkó ti o ja fáfá.
Ohun meji pataki ni o nfa irú ìkùnà yi. Èkini nip e èdè Yorùbá ti a nko sile máa nyàtò ni ìgbà pupo si èyí ti a nso l’enu, o si máa nsòro lati ko awon òrò miran yanjú. Bí o ti wù ki eni kan gbó èdè Yorùbá siso lénu tó, afi bi o ba mò bi a tin pin àwon òrò síso si òtòòtò bi o ti ye; ki o mò àwon òfin kíko àwon òrò ti o máa nni ohùn pípaje nínú sile; ki o sì ni òye bi a ti nfi àmì si orí àwon òrò meji, meta, tabí jù béè lo, ti nwon máa nfi ara jo ara won lati lè fi ìtumò olúkuluku won hàn yàtò, yio sòro fun un lati lè ko ìjìnlè Yorùbá sile yanjú.
Idi keji ni pe awon ìwé Yorùbá ti a lè lò fun kíkó àwon omo ile-èkó giga ni ìjìnlè Yorùba lónà ti yio yé enikeni kò i pò tó béè. Pupo nínú àwon ti o wà kò nní àlàyé tó nipa ìlànà àwon òfin ti o lè tó àwon akéko si ònà nipa bi a se nko èdè náà sile; orisirísI àsìse ni o sì máa nwà nínú ònà ti nwon fi nko àwon òrò inú opolopo àwon èkó inú won. Pelupelu, èdè Gèésì ni pupo àwon ti o se irú iwe béè máa nlò lati fi kó awon akéko ni èdè Yorùba! A kò rò pé eyi bá ojú mu rara.