Okediji, Oladejo: Opa Agbeleka
From Wikipedia
Oládèjo Òkédìji (1989), Òpá Agbéléká. Ìkèjà Nigeria: Longman Nigeria Ltd. ISBN. 978 139 307 7. Ojú-ìwé 67
Ajéwolé kò rí omo bí: Àjàlá ń ronú ònà tí yóó fi rówó sìnkú àna rè; Lápité parí isé tó ń kó, kò mònà ib i tí yóó dorí ko. Lókòòkan, ohun tó bèrè àwon ìtàn inú ìwé yìí nìwònyí. Àsé, àsèsèjáde akàn, a ò mobi tó ń lo! Keesekeese la kókó rí, láìmò pé kààsàkààsà ń bò léyìn. Béè sì ni kàásàkààsà ni baba keesekeese! Ohun tó wà léyìn Òfà kì í segbé Òje. Òpá àgbéléká ni, tèyin ló jù. OLÁDÈJO ÒKÉDÌJÍ ti ko òpòlopò ìwé tí ogunlógò ònkàwé ń gbédìí fún. Lára won ni Àgbàlagbà Akàn ati Àjà l’ó l’erù; eléyìí náà kò sì kèrè nínú isé owó rè, Ogbón ìkòwé tó ń lò télè náà ló tún fi ko ìwé tuntun yìí; àfi pé mòrìwò ni àwon ìwé tó saájú, eégún gidi ni eléyìí. Òpá àgbéléká, tèyìn ló jù.