Ogedengbe

From Wikipedia

Ogedengbe

Ogedengbe Agbogungboro

Olusesan Ajewole

Ajewole


Olusesan Ajewole (1986), Ògèdèngbé Agbógungbórò. Ibadan, Nigeria: Heinemann Educational Books, (Nig) Ltd. ISBN 978 1292261 ojú-ìwé 78

ERÉ NÁÀ NÍ SÓKÍ

À ó rí i pé ìségun àwon Ìbàdàn àkókó lórí àwon Ìjèsà ni ó fún Ògèdèngbé ní agbára àti àníyàn láti gbàradì láti gbèsan lára won. Ìdi niyi tí ó fi kó ìba àwon omo ogun béréte tí ó kù jó, tí ó sì fi orí lé ònà ibi tí ó gbó pé àwon Ìbàdàn wà, tí ó fi gbònà Èfòn-Aláayè, Arámoko dé ùyìn ní ibi tí ó ti pàdé àwon omo ogun Ìbàdàn, nibi tí ó ti ségun won ní Òkè-Tòrò pèlú ìsowópò àwon omo ogun Ùyìn. Ògèdèngbé ò kúkù dúró níbí yìí nìkan, ó tún gbònà Ìgbàrà-òkè jáde sí Àkúré. Bí ó ti ń lo yìí náà ni ó ń jagun lo rabindun tí ó sì ń ségun. Ta ni tó kò ó lójú? Ó fé ja Àkúré lógun àìròtélè, sùgbón àsírí rè tú, ó jewó, wón sì di òré, kódà ó ràn wón lówó nípa bí bá won jagun Ìsè. Léyìn tí Ògèdèngbé kúrò ní Àkúré, ó fi orí lé ònà Àkókó tí ó sì ń jà lo bí ààrá kí ó tó lu jáde sí Ifón léba Òwò. Ifón yìí ni ó gbà padà sí Ìta-ògbólú tí ó wá fi se ibùjoko rè. Ìgboyà, akíkanjú, ifaradà, ìfàyàrán, aáyan, làálàá àti ogbón Ògèdèngbé yo nínú eré yìí gedegbe. Àwon nnkan wònyí náà ni ó sì fún un ní àwon ìségun rè gbogbo lórí àwon òtá rè. Kí ng má fi àròyé gbà yín lákoko, e kúkú máa gbádùn eré náà lo, oyin-àdò ni, ìran sì ń be níbè tété.