Asa Yoruba III
From Wikipedia
TIAMIYU ADAMO GBADEBO
ÀSÀ YORÙBÁ
Yorùbá jé òkan nínú àwon èyà tí lajú jù lódé ayé yìí. Láti ìgbà tí aláyé ti dáyé ni wón tí ní ètò àti ìlànà nípa ohun gbogbo tí wón ńse ní ìgbési-ayé won. Bí-o-tilè jépé kò sí àkosílè àwon ètò àti ìlànà wònyí, gbogbo won ni àwon Yorùbá mò tí wón sí ńlò lójóojúmó títí ó fid i bárakú tàbí àsà fún won. Ara àwon àsà náà nìyìí: Ìkínì àti ìjéni, ìdèyún ati ìgbèbí, ìkómo àti ìsomolórúko, ìranraenilówò, ìsìnkú àti ogún jíjà àti oge síse.
Ètò tún wà fún ìjoba síse, isé síse, isé kíkó, ogun jíjà, ìjà lílà, ebí síse àti adura síse. Mímò àti tílèlé àwon àsà àti ètò ìbílè Yorùbá nínú ohun gbogbo se pàtàkì púpò láàrin won. Eni tí ó mo àwon àsà àti ètò wònyí ni a ńpè ní omolúàbí àti ologbón. Eniti kò bá mò wón ni a ńpè ni òbùn, òmùgò tàbí asìwèrè.
Gégé bí ati sàlàyé soke, òké àimoye nì àsà àti ètò Yorùbá sùgbón fún ànfààní àpílèko yìí, àwon méjì ni a máa gbé yèwò níbè. Àwon méjì yìí náà ni: Ètò ebí nílè Yorùbá, àti Ìwà omolúàbí.
ÈTO EBÍ NÍ ILÉ YORÙBÁ
Ebi ni baba, ìyá ègbón àti àwo ìbátan. Lónà kíní a ní láti mò wípé ebí se pàtàkì. Yorùbá sì jé òkan pàtàkì làra èyà tí ó wà láyé tàbí ní ilè Afíríkà tó jé pé àwon nìkan ló ni nnkan tí wón ńpè ní Òkè Ìpònrí. Nínú Òkè ìpònrí yìí ni ebí ti ńjáde wá. Bí òrò bá lé koko bí ojú eja, tí àwon ènìyàn bá so pé “má bínú mo fi alájobí bè ó”, tó bá jé omo Yorùbá yóò fi òrò náà síle.
Àjobí náà ni ńjé baba, ní í jé ègbón, nì í jé àbúrò ní í jé ìbátan ní í jé ìyekan. Ó se pàtàkì pùpò tó béè gé tí ó fi yà tó sí ti àwon Òyinbó tí wón ńpè ní ‘Family’. Yorùbá máa ńtan ebí títí yóò, fi so òpòlopò ènìyàn pò. Àwon Yorùbá gba ìyá àti baba bìi ìgbà tí ènìyàn gba Olórun ni; nítorí Ifá ní ńse Amònà won. Odù Ìfá kán so pé:
Òkún kún nàrenàre
Òsà kún lègbelègbe
Alásé ńrase
Alásè ńràsè
Àgbàlagbà ímàle wò gbèhìn òrò
Títí, ó gbòndíí rè pépépé
Ó dífá fún ìsèse tí i solórí
Orò lálè Ifè.
Baba eni ìsèse eni, Iyé, eni
Ìsèsè eni, orí eni ìsèsè eni.
Kí là bá bo kà tó bòrìsà
Ìsèse là bá bo, ká tó bòrìsà?
Ìsès là bá bo.
Ifá ni kí o tó bo Sàngó, kó o tó b’Oya, kó o tó b’Èlúkú, kó o tó b’Òsósì, kó o tó bo Yemoja, kó ó tó b’Ògún, kó o tó bomolè, ó ní, ìsèse ni kí o kó bo. Kó o bo baba, kó o bo ìyáà re. Àwon Yorùbá gba pé Òké ìpónrí ní baba àti ìyá jé.
Nínú ebí, enìkan kì í dálé kó kó dá a gbé, agbo ilé ni àwon Yorùbá máa ńgbé. Gbogbo ebí ni yóò jo máa gbé inú ilé kan náà. Omo inú ilé pàápàá tó bá jé obìnrin tó bá lo sì ilé oko tí ilé oko kò gbà á, tí ó padà wá sínú ilé-won ni wón ńpè ní omo osú.
Nínú ilé, nígbà tí ènìyàn bá pò, olórí yóó wà. Yorùbá kìí fi òrò àgbà seré. A ti ńje Olórí ní ilè Yorùbá kó tó di pé àwon Òyìnbó dé. Eni tó bá jé àgbàlagbà jùlo nínú ilé ni í je “baálé”. Bí oyè bà sì kan àgbo ilé náà, eni tí ó jé àgbàlagbà jùlo ni wón fi í je é. Sùgbón nísisiyì, owó ni àwon ènìyàn-an wá ńfí se é, Òwo loyè. Èyí burú púpò, àwon baba wa kì í se béè. Àwon baba wa máa ńse e bí won tí ńse é. òun ni í jé kó rí bó ti ńrí. Bí olórí ilé kan bá sí kú, kì í se àrèmo rè ni yíò tún je baálè, eni tó bá tún dàgbà jùlo ni wón fí ńjé é. Bí irú eni béè bá di baálé tán áwon ìyókù yóò máa se sí i bí òun náà ti se hùwà sí baálé ìsáájú. Bí òrò kan bá sì délè àwon àgbà ni won máa ńso ó nítorí náà ni won fi ńso pé ‘àse mbé lénu àwon àgbà’.
Kò sí Baálé tí ó ńfé ki ilé tú mó òun lórí, nítorí irú eni béè kò ní fé kí wón pa ìtàn buburú nípa òun, nítorí Yorùbá féràn ìtàn púpò. Bí o ba fi ìtàn bú Yorùbá, wón kì í dárí ji ni. Òrò a máa dùn Yorùbá. Yorùbá kì í sìí fé se nnkan ìwòsí tàbí je oúnje iwòsí nítorí ìtàn pípa.
Bí ti baálé ilé náà ni ti àwon obìnrin ilé, Olórí àwon obìnrin ilé ni wón ńpè ní “Iyáa káa” èyí si ni eni tí ó jè àgbàlagbà obìnrin jùlo, òun ni yíò parí ìjà tábì aàwò tó bá sùyo láàrin àwon obìnrin ilé. Ní ayé òde òní, ó dàbí enipé ebí tí ńyá, sùgbón bó ti ya tó, nnkan tí won fí ńsebí ó ye kí à sì máa lò ó. Kí a fi orí fún eni tí orí ńse tirè. Òrúnmìlà ní:
Olórí ni à ńforí fún
A dífá fún èrinméjo irúnmalè
Níjó ti wón ńrelé Olódùarè lo sodún.
Eni tí o bá jé Olórí, a ní láti fí orí fun un.
Béè náà ní ètò ti omo ìyá, gbogbo èyí ni àwon baba wa ti tò. Wón gbà pé gbogbo eni tó bá ti saájú eni dáyé ju ni lo, a sì níláti máa bu òwò fún won. A kò sì gbódò yájú sí won nítorí, “Ení bá fé dàgbà kò gbódò gbòpá lówó arúgbó”. Enikéni tó bá ju ni lo, ìdòbálè ni wón máa ńki wón, bí wón bá tí je mòlébí. Gbogbo ètò wonyi máa ńmú kí ilé gún ni. Fún àpèère, bí enikan bá fé fi omo fóko, olórí ilé ni ó ni ètò à ti fi fún un, nítorí wón ńfé kí gbogbo ilé lówò si ohunkóhun tí ó bá tibè súyò. Àwon àgbà wònyí ló sì máa ńfàse sí ohun gbogbo, bó jé ìjà ni, àwón ni yóò paríi rè. Olórí ilé yì lé sàìlówó, sùgbón ní ti ojó orí, òun ni yíò se olórí.
Orogún ní ètò tí àwon baba wá ti fi lélè fún won. Sùgbón àwon obìnrin iwòyí kò se é bí won tí í se é, òun ni kò jé kó rí bi í tí í rí. Èkíní, ìyàwò àkógbé kò sé é, fí seré lówó àwon baba wa. Ìyàwó àkógbé ni àwon baba wa máa ńsètò ohun gbogbo fún, àwon ni wón máa ńsorò gbogbo fún títí dára bí oko bá se fé soorun, gbogbo èyí ni ìyàwó àkógbé tàbí ìyàálé yì yóò mò pátá. Ìyàálé yí sì máa ńfún omo orogún lómú, sùgbón àwon tòde òní kò le è sé é rárá. Èyí sì máa ńmú àwon orogún se bí omo ìyá. Eni tí ó bá so pé Yorùbá kò mètò, iró ńlá ni, àfi bí won kò bá fé se é. Gbogbo ètò bí a ti ńse ìbátan ni àwon baba wa ti fi lélè. Àwon baba a máa kìlò fún àwon omo wón ohun tí wón kò fé kí wón se bí-ó-tilè-jépé ààrin ìbátan kan ni.
Òrúnmìlà so pé:
Bí omodé bá fé hùwà ògbójú
Tó bá ri ògbó awo kó gbá a lójú
Bí ó bá ri àgbà òsègùn kó je é níyà
Bí ó ba ri aáfàa níbi tó gbé ńforí balè fún Olórun,
Kó dojúu re délè
Á dífá fún àwíigbó
Omo tó ńlùgbó awo
Tí ńjà gbà sègùn níyà
Ó rí alùfáà níbi tó gbé nkirun
Ó dójú è dé lè
Òrúnmìlà ní kí e fi sílè, Ó wá fi yé won pé:-
Àjepé ayé kò sí fomo tó lùgbó awo
Àtelèpé ò sí fomo tó lùgbà òsègùn
Omo tó dojú àfáà délè níbi tó gbé ńyin Olórun Oba
Owó ara rè ló fí ńwákú
Wàràwàrà nikú ìdin, wàràwàrà.
Oríkì a máa fi ebí hàn, a máa mbí àbíjo. Won a máa pa ìtàn fún ni pé ‘báyi ní eléyì rí. Òmíràn wà láàrin àwon ebi nígbà tí ilé bá kan ilé bayí, tí òré bá wo ara won nínú mòlébí, wón a dòré wón a dìyekan. Àwon Yorùbá ìjelo, bí òré bá pò ti òré bá wonúara wón títí, won kì í fé ara wón. Wón rò pé ó ti di mòlébí. Nítorí pé wón féràn ara wón púpò, wón wá di pé mòdàrú dé, ilú míràn wà ní ilú òkè, tí a ó rì olópa mérin péré ní bè. Fún àpeere, nígbà tí mo wá ní Ògbómòsó-ìlú keta tó férè tóbi jù ní Nàìjíríà-ní nnkan bí i 1930-Olópá tí ó wà ní ìlú náà kò ju mérin lo. Ilé èwòn, etí Òsogbo ló wà. Ìdí ni pé wón mo ètó. Ewúré á wà níta, bó o sáso kò s’éni tí ó ká a, ká to wá pé enìkan mú ìbon lówó. Bí ijà dé wón ó paríi rè nínú ilé. Bí won kò paríi rè nínú ilé, wón ó lo òdòo Baálé àdúgbò. Bó bá dè òdò alàgbà a jé pé olúwa rè dáràn nìyen. Bí a bá gbó pé onísé baálè ńpè ènìyàn elòmíràn a sá gún òkè àjà. Àwon elòmíràn so pé ìjoba yìí kò mú ìlosíwájú lówó. Sùgbón kí á so pé owó tí ìjoba òde òní ńlò lórí olópá, tó bá jé pé wón fi se omi sí Èkó ni gbogbo wa ni ìbá máa rómi mu. Bí wón bá fo ńtanná ni, yóò dé ìlú òkè. Nítorínáà àwon baba wa ní ètò tó dára púpò. Eléyí ló jé kí wón lé gbé ayé bí a tí ńgbé ayé. Àwon baba da ara wa. Ká sòtító. Ká pón ara wa lé. Ká kó ara wa ní ìjánu. Òrúnmìlà ní:
Ìwòrí tejú móhùn ti ńseni
Bá a bá tè ó nífá tán
Kó o tún raà rè tè
Ìwòrì tejú móhun ti nseni
Awon má féjà igbà gun òpè”.
Mó pé ńtorí pé o ti sawó kó o fi igbà tó ti já tán gun òpè.
Ìwòrì tejú móhùnto ńseni
Awo mó fibínú yòbe”
Ìjà kì í dé kórò gún ra won káwo wólé yòbe
Ìwòrí tejú mo hunt i ńseni
Káwo mó sán bànté Awo.
Itumòo rè ni pé, e má bá araa yín lóbìnrin sùn. Iyàwó Awo ni ibànté Awo. Won ní olúwa eni kì í bíní léèrè òrò ká sé. Bá a bí ó léèrè òrò so òtító. O ò gbódò sàsèjù nípòkípò tó o lè wà. Má se rá omo ènìyàn je.
Ká má fi kánjúkánjú jayé,
Ká má fi wàràwàrà jákùn idà
Òrò tá a bá fi sà gbà, kámá fi se bínú
Tá a bá débi tó tutu
Ká sinmi sinmi
Òrúnnmìlà ní ká wo wájú ojó títí títí
Ká wèhìn òràn sun un
Nítórí àti sùn eni
“Ati sùn” ni pé, nítorí ojó ìkéhìn. Torí Yorùbá a máa ran ‘ró. Bí Yorùbá kò bá ran’ró kò ì tí ì ráyè ni; nítorí wón so pé:
Bí owó omodé kò bá te eèkù idà
Kì í beèrè ikú tó pa babaa rè.
Wón ní àkódá oró kò dàbí àdágbèhìn. Nítorí èsan ni Yorùbá se máa ńsa fún láìfi araa wón. Yorùbá kì í ja ìjà èbi.
Eke síse kò pé á mò lówó lówó
Ilè dídà kò pé á mò dàgbà
Ojó atisún lebo.
Eléyìí jé ètò Ebí àwon Yorùbá.
ÌWÀ OMÓLÚÀBÍ
Lóde òni, ó dàbí eni pé gbogbo ohun mèremère àti ohun èsó tó ńtún orílè èdè se wón ju ti àtijó lo. Ñnkan abàmì, ñnkan abànìyànlérù ni a sì ńgbó nígbà gbogbo. Emi kò fé kí e rò pé kìkì ohun ìbèrù yìí nìkan ló wà nílèe wa, ohun rere náà wà níbè. Sùgbón ohun tí mo fé tenu mó ni pé nígbà tí ìwà omolúàbí bá ti ńdinkù ní orílè-èdè, ìwà buburú, ìwà abàmì tí kò bójú mu yìí ni ó sábà ńgorí ìwà rere àti ìwà omolúàbí.
À ńgbó nípa olè, à ńgbó nípa kólékólé à ńgbó nípa dánàdanà, à ńgbón nípa gúnbegúnbe, à ńgbo nípa àwon jàndùkú, à ńgbó nípa ayolé ayo-òde-lénu. Njé gbogbo ìwònyí dára láti wà láàrin orílè èdèe wa bí? Kí ó tó di pé a dáhùn ìbéèrè yen a lè so pé, lénu ìgbà ti ojú wa dá yìí, ó dàbí eni pé ayé dára jú eléyì lo. Ó dàbí eni pé ènìyàn lè gbé ñnkan rè síwájú ahéré rè kó sì bá a níbè, o dàbí eni pé obìnrin lè lo ségi lóko kó pa àlà lé e lórí tàbí kó pa ààlè lé e lórí kó sì bá a níbè. Sùgbón láyé ìsinsìnyí, èyí tí ènìyàn ló gbà pé bí owó bá wà nínú ilé ìfowópamósí kò sí ohun tó lè se irú owó béè. Ayé àtijó ni a ti ńso pé a kì í fi ojú bòrò gbomo lówó èkùró. Ó ti wá di pé àtomo èkùró ni o, àti èkùró ni o, ojú líle àti ojú bòrò, gbogbo rè la ńpapò láti gbomo lówóo won. Ohun tí mo ńtoka sí nísìnyí ni pé ìwà omolúàbí dàbí enipé ó ńdín kú díèdíè. Béè ni láyé àtijó iyì ńláńla ni láti pe enìkéni ni omolúàbí. Àlàyé omolúàbí yíì ni mo fe kó yé wà kedere. Kì í se eni tó bá lowo lówó nìkan soso la ńpé lomolúàbí. Kì í se òjògbón, kì í se gbajúmò. Nílè ‘E káàárò e ò jí i re’ wa yí, eni ti a ba pè lómolúàbí ni eni ti ó kó gbogbo ìwà rere pò, ti o sì jé eni tí elégbé àti ojùgbà kà sí ojúlówó ènìyàn. O dá mi lójú, ó sì dá àwon ará ilè Yorùbá lojú pé, ìwà rere, òun ni èsó ènìyàn. Àti pèlúpèlù pé orúko rere, gégé bí a se ńso o ni òwe ilèe wá, dára ju wúrà àti fàdákà lo. Nígbà tí mo ti so fún yín irú ènìyàn tí a lè pè lómolúàbí yìí, e lè fé máa tóka sí enìkan tí e bá mò pé a lè pe eni yí ní ómolúàbí. Ojúlówó omolúàbí sòwón; sùgbón síbèsíbè, à ńrí díèdíè lárá wa.
Omolúàbí ni eni tí ó sábà ńní ohùn rere lénu, torí pé ó mò dájúdájú pé òrò tí ènìyàn bá so lénu ló ńfi hàn bí okàn àti inúu rè ti ri. Gégé bí a se máa ńso lórò àwon àgbà pé, ‘Ohùn rere ló máa ńyo obì lápò’, ó sì tún dájú pé, ofà ni ohùn buburú ńfa jáde lápó!’Kàkà kí omolúàbí sòrò buburú lénu ó máa ńdáké ni. Èyí tí àwon ará òkèèré ńso pé; ìpa-enu-eni-mó ni àkójá òfin.’ Bó tilè jé pé omolúàbí mo ìgbà tí ó ye kí ó máa dáké, bákan náà ló sì mo ìgbà tí ó ye kí o máa la enu rè. Nítorí pé, omolúàbí a máa kí ènìyàn pèlú ìyési àti òwò. Kò séni tó so fún omolúàbí pé, ‘eni tí kò kí ni kú ilé, o pàdánù e kú abò,’ nítorí pé ó mò dájúdájú pé bí òun ò bá ti kí ará ilé kú ilé, sírisírí ni àwon ará ilé ńse sí ni. Nítorí náà, ni àárò ni o, ni òsán ni o, ní alé ni o, seni omolúàbí máa ńyá mó ènìyàn, tó sì tún ńkí aládùgbò rè tinútinú, pèlú ìfé àti pèlú inú rere. Omolúàbí kì í yodì, kì í féèyàn sínú. Ó mò, ó sì dá a lójú, pé: érùu ‘hò’ kì í wo ènìyàn lórùn. Bákan náà ló sì tún fi sókàn gbákogbáko pé “eni tí kíkíi rè kò yóòyàn àìkíi rè kò lè pàni lébi”. Kò sì lè pani pàápàá. Nítorí ìdí èyí, ó máa ńjé kí òrò ìwúrí àti òrò ìyánilórí jáde lénu òun.
Kíkí tí omolúàbí ki í se irú èyí tí à ńfi èjè sínú tu itó fúnfun jáde lénu. Irú èyí tí ó ti oókan okan rè wá ni. Torí pé omolúàbí náà fúnra rè mò pé, ‘Akíni ńjé akíni, afinihàn ńjé afinihàn, èwó ni pèlé o ará Ìbàdàn lójúde Sódeké?’ Omolúàbí kò ní je kí kíkíi rè ni asò tàbí afinihàn nínú. Se a mò pé òrò tí ó bat i enu wa jáde ni a ó fi mò gégé bí inu se rí. Bákan náà omolúàbí a máa gba òrò aládúgbò àti ojúlùmò àti àwon elòmíràn béèbéè yèwò. Bí elòmíran bá wá ní ìsòro, omolúàbí yíò gbìyànjú láti mú ìsòro rè kúrò tàbí dín in kù. Láìsiyè méjì, omolúàbí mò kedere pé, ‘bí ará ilé eni bá ńje kòkòrò buburú, bí a kò bá tètè so fún un, hèrèhuru rè kò ní jé kí á sùn lóru.’ Nítorí náà ńkó, omolúàbí kì í fi iná sí orí ilé kó lo sùn sábée rè.
Síbèsíbè, bí omolúàbí bá ti ńse òrò ni ó máa ńfi ogbón se è tó béè géé tó jé pé kì í sábàa ré kojá aye rè. Èyí ni pé kì í se àsejù tàbí, lórò míràn ńkó, omolúàbí ènìyàn kò gbódò ti ojú eni tí ó bá ní ika mésán kà á. Omolúàbí a máa lo ogbón orí ará rè láti fi se àwon ñnkan jànkanjànkàn tí ó tó sí i láti se sùgbón a máa se é pèlú ìrèlè. Kò di ìgbà tí àwon ènìyàn bá ńse àfojútóo rè, kò di ìgbà tí ó bá ńsisé lábé ààbò àwon elòmíràn kí ó tó máa tún omolúàbí rè se. Ó máa ńse ojúse rè ni, bó tilè jé pé ènìyàn wa níbè tàbí kò sí níbè. Omolúàbí máa ńfi kíkí se òrò àwon òjògbóm pe bí a bá rán ènìyàn nísé erú a ó fi jé tomo. Ju gbogbo rè lo, omolúàbí ènìyàn mò, ó sì ńhàn ni ìsesíi rè pé, èhìn ni ogbón ti ńwá. Gbogbo omolúàbí ló ńgbédí sókè fún òrò tí àwon àgbàlgbà sáabà ńso pé “ogbón ológbón kì í jé kí á pe àgbàlàgbá ní wèrè.” Ìdí pàtàkì tí omolúàbí fi ńfi oókan àyàà rè gba ìmòràn láti àsìkò dé àsìkò nìyí. Omolúàbí a máa jé kí ogbón bá òun gbé nígbà gbogbo, a sì máa fa ènìyàn móra.
Mo rò pé mo ti so nísájú pé omolúàbí kì í lodì, sùgbón, e jé kí n se àfikún òrò náà dájú báyí pé, bí enikéni bá sè omolúàbí yóò rántí pé, ‘sè mí n bí é ni oògùn òré, Ñnkantó jé ki n fa òrò yí jáde ni pé, bí a bá so pé èhìn ni ogbón ti ńwá, ti omolúàbí ènìyàn sì fé gba ogbón náà ńkó? O lè máa tì torí ìrékojá àwon tó ti èyìn rè wa, kó fé máa ko èhìn sí òrò ogbón. Èyí ni pé ti a ba pé ènìyàn ní Kòfésò, tó bá sì je pé Olùkóni wà lábée rè tó so pé alàgbà “Òrò té e só yen kò bójú mu o”. tó bá fé jéni tí kò fé sò ni, ó máa gba òrò yen yèwò. Èyí ni pé ó ni láti mò lésèkésè pé eni ti ó sòrò latièhìn wá yen tún wa ní ipò láti rí òrò náà ni kodòro ju òun lo. Omolúàbí a máa dúró si àyè rè nígbà gbogbo, òun náà ni mo ti só nísàájú pé kì í sègbà gbogbo ló ńkojá ípòo rè. Ó mò pé ‘ilé ni mo ńgbé kì í jèbi ejó! sùgbón síbèsíbè ó ní láti máa yojú sí òrò nígbà tí ó bá ye kí ó se béè. Àkókò fún ará rè ni ó sáab’`a máa ńsàpèjúwe ohun tí ó ye kí omolúàbí se. Bí omolúàbí bá ti ńdàgbà sí i, bákan náà ló ní láti máa rántí pé òun ní láti máa kùgbé òrò tí ó ye kí òun se nítorí pé ohun tí ó yé ológón ni pé “à gbà kì í wa lójà kí á jé kí orí omo tuntun wó.” Èyí ni pé bí omolúábí ènìyàn bá ti ntóbi si ní ìbùgée rè, ní ìlúu rè, ní orílè èdèe rè lo ni láti máa gbà pé isé àti ètò ti wón ni láti máa se sí sàkání òun ní láti máa pò sí ju ti àtèhìnwá lo. Kì í se àwon ti o ba tobi julo nìkan soso ni omolúàbí ní láti máa bòwò fún. Bí ó bá ti ńbu olá fún àgbà ni yóò tún máa se fún àwon omodé nítorí pé òun náà ti mò pé, ‘bí omodé bá ti mò owó ó wè ó ní láti lè bá àgbà jeun.’ Jù gbogbo rè lo, omolúàbí ní láti máa fi sí okàn ará rè pé, ‘a kìíru eran erin lórí kí á máa fi esè tan ihò ìrè nílè.’ Èyí ni pé, ó ní láti gbà pé ayé òde òni tí a wá, ayé òpòlopò ènìyàn ni. Ó ní láti mo wí pé ‘je kí n je òun ló ńínú ayò ó dùn’. Ó ní láti mò pé bi eni méjì bá gun orí esin, dájudájú enìkan ní láti wà níwáju enìkan sì ní láti wà léhìn. Ó sì ní láti mò pé ìgbà tí owó òtún bá we òsì, tí òsì sì we òtún ni owó ńmó.
Nígbà gbogbo, níbi gbogbo ni omolúàbí ní láti jé kí á bá ìsesí tí ó yeni lówó òun àti lódò òun. Ohun tí ó bá ní láti mú ìfura wa ní láti jìnnà sí òdò omolúàbí. Omolúàbí kò gbódò bá oníwà buburú tàbí alárékéréké rìn pò, nítorí pé, ‘àgùtàn tí o bá ti bá ajá rin dandan ni ki ó je ìgbé’. Ó sì ni láti mò pé, ‘a kì í pe ni lólè ki a máa gbé omo eran seré’. Lórò kan ńkó, omolúàbí kò gbódò lówó si ñnkan tí ó lè ba omolúàbí rè jé. Kò gbódò sí ìwà pálapàla, àìsedéédéé, àgàbàgebè ni sàkání rè. Ohun pàtàkì tí omolúàbí ni láti rántí ni pé, ‘E jòwó, e gbà mí’, kò ye egúngún, ‘eranko ni ńle mi í bo’ kò ye ode. Èèwò ni gbogbo ohun wònyí. Omolúàbí kò gbódò jèèwò. Ìhùwasí omolúàbí ní láti bójú mu. Ìhùwàsí rè sì ní láti bó sí ohun tí àwon olódodo ènìyàn ńreti láti òdò rè. Ta ni kò mò pé, ‘àifenipeni àìfènìyànpènìyàn ni ńmú ará oko sán bànté wòlú’. Ká má ri, omolúàbí kò jé sán bànté wòlú. Ìgbésí ayé omolúàbí ni láti je àpeere ìtèsíwájú fún ànfààní ìlú rè àti orílè èdè rè.
Láyé ìgbàànì, èyí ni láyé àtijó, nígbà tí monááfìkí mo ní ìbá, tí ayé kò tí i lu jára, ògòòrò ènìyàn ló fé kí á ka àwon kún omolúàbí. Nísínsìnyí, àféjù ohun ayé, àsejù fàájí, àìlóue mípa ohun tí ó se kókó nígbesí ayé omo ènìyàn ti jé kí òpòlopò ènìyàn fi ìwa omolúàbí won sílè. Àwon mìíràn ti je kí àwon àsà ilè míran gba àwon àsà iyebíye ti ìsèdálèe wa nù.
Àwon mìírán rò pé òlàjú ni pé kí a ko èhìn sí àwon ohun tí ó jé tiwa láti ojó jojo séhìn. Ó jé ohun tó dun ní láti rí i pé a ní láti máa se àtunyèwò okàn wa láti rí i pé àwon ìhùwasí wòonnì tá a fi í mo omolúàbí. Sùgbón gégé bí gbobgo wa ti mò, ‘bí òwe bí òwe ni a ńlú ìlù ògìdìgbó, ológbón ni í jó o, òmòràn ní í mò ó’. Omolúàbí nìkan soso ni ó mò bí a ti ńjó ìlù ògìdìgbó òun ló sì ńmo ñnkan tí afi ńjó o, òun ló sì mo ìtumò orin rè.
Àwon olùkóni ni ipa ńlánlà láti sà nípa àti rí i pé omolúàbí pò ní ilèe wa. A lè so pé àpeere dára jù òfin lo. Nítorí ìdí èyí ni pe ó ye kí àwon olùkóni fi àpeere ìwà omolúàbí hàn ni ilé èkó, ní ilé ara won. ní ìlú won ati ni orílè èdè won Ònà kan soso náà ni yen torí pé bótilèjépé à ńfi àpeere yìí hàn nígbà gbogbo tó bá jé pé ohun tó yí wa ká pò jù wá lo tàbí tó bá jé pé, ó ni ìba tí àpeere wá lè hàn mo, a tún rí ònà mìíràn tí a lè fi fi ìwà omolúàbí han òpòlopò ènìyàn.
Ñnkan tí kò jé kí àwòn ènìyàn mò nípa ìwa omolúàbí ní ayé àtijó ni pé àkosílè wa kéré púpò. Tó bá yè ni àwon ñnkan tí a tè sí opón Ifá, ìba àkosílè díè ni a rí ní ilè Yorùbá. Ó lè jé pé ní ojó iwájú a tún lè gbé ilè kan àwon ìwé tí eèrà tàbí ikán kò tí ì je. Èyí ni tó bá jé orí òkúta ni won hán án sí a sì lè mò bóyá àwon ènìyàn wá ti ko àkosílè. Sùgbon láì sí àkosílè yí, mo fé é so ní ìparí òrò ni pé láàrin àwon omo ilè Yorùbá eni tó bá kó ògo já ni à ńpè ní omolúàbí. Omolúàbí yìí sì ní láti se é títí di ojó tó máa kó ògo yen já. Nítorí pé kì í se ojó yìí nìkan soso ni omolúàbí ńwò. Ó ńwo ehìn òla nítorí ó mò pé bí òsìkà ènìyàn bá kú rere, ó lè má sùn rere. Nítorí náà ńkó, omolúàbí a máà fé kí òun ó kú rere kí òun sì sùn rere.