Ole Jija
From Wikipedia
Olè Jíjà
Òkan nínú àwon ìhùwàsí èdá ní àwùjo ni olè jija. Kò sí ohun tí ó ní ojú tí kì í ní òdì. Bí àwon kan se ń tiraka láti sisé béè ni àwon èdá kan yóò máa ronú ònà láti je lára isé tí won kò se. Bí àgbè se ń pàjùbà tí ń pa èèbù béè ni eni tí yóò ji isu wà yóò ti máa ronú ònà láti rí isu òhun jí wà. Kò se é se fún olè láti jé omolúwàbí. Eni tí ó jé omolúwàbí yóò jé onísùúrù. Onísùúrù mò pé bó pé bó yá òun yóò ni nnkan láìjalè. Bákan náà, eni tí ó ní ìtélórùn kò le jalè. Ìwà olè jíjà ta ko gbogbo abala ìwà omolúwàbí yòókù pátápátá. Olè jíjà a máà fa òfò àti ìnira fún olóhun. A kò le ka èdá ti ìwà rè kò fún àwon alábàágbé rè ni àlàáfíà sí omolúwàbí. Orísírísìí nnkan ni ó lé sún èdá dé ìdí olè jíjà sùgbón bí ó ti wù kí ó rí, kò ye kí omolúwàbí jale. Enikéni tí ó bá jalè ti ba omolúwàbí ara rè jé. Ó ti ba orúko ara rè àti orúko ìran rè jé Yorùbá bò wón ní, eni jalè ní òní bí ó pé ogún odún tí ó da àrán borí aso olè ni ó dà bora.
Bí ó tilè jé pé kò sí àwùjo tí olè kò sí, síbè, wón pò ju ara won lo láti àwùjo dé àwùjo. Àwùjo Yorùbá àtijó gan-an kò tilè ní olè tó ti òde òní.
(Awótáyò 1997:36-37) sòrò díè lórí olè jíjà pé;
Gbogbo gbajúmò kó lènìyàn rere
Mo ko fàyàwó
Mo ko olè jíjà
…Orí ámìrobà a ro níwájú ìbon ológun
Mo kò ó
Mo ko isé burúkú
Mo ko ise ibi
Nínú àyolò yìí Awótáyò fi ìdí rè múlè pé gbogbo gbajúmò kó ni ènìyàn rere. Ó so pé isé burúkú, isé ibi ni olè jíjà, ó sì so pé òún ko irú isé béè, olè jíjà kì í se isé omolúwàbí ní àwùjo Yorùbá.
Odúnjo (1993:46) ti parí òrò ta2n nígbà tí ó kéwì pé:
Kí ni ó folè se láyé tí mo wá
Kí ni ó folè se láyé tí mo wá
Ayé ti mo wá
Kàkà kí ń jalè
Kàkà kí ń jalè
Ma kúkú derú
Kí ni ń ó folè se láyé tí mo wá
Ewì yìí sàlàyé pé dípò kí èdá máa jalè. Ó sàn ki onítòhún kúkú di erú. Bí ó tilè jé pe orísìírísìí èyà ni ó wà ni ilè Nàìjíríà nínú èyí ti Yorùbá je òkan. Òlàjú tètè dé àwon àwùjo tí wón mú ilè kan òkun. Àwon ìlú bí Eko jé ìlú etíkun tí àwon eebo òyìnbó omo afòkun sònà gbà wo Nàìjíríà. Ìlú pàtàkì ni ìlú Èkó jé ní àwùjo Yorùbá. Òlàjú wolé olè jíjà sì tè lé e ní àwùjo Yorùbá. Gbogbo omo Yorùbá pátá ni òrò àwon olè ń ko lóminú. Orlando gbà pé nígbà mìíràn àwùjo tàbí ìhùwàsí ìsòrí kan sí èkejì nínú àwùjo a máa fa olè jíjà. Bí àpeere:
Lílé: A rí lara officer tó kó wa lówó je
A rí lára Bank manager
Tó ti kó gbogbo owó wa sowo tan
Nínú orin òkè yìí Orlando sòrò àwon ògá ńlá ńlá ni ilé isé ìjoba títí kan àwon ògá ilé ìfowópamó tí wón ti ji owó àwon ará ìlú.
Àwon èèbó amúnisìn ni wón mú ètò ilé ifówòpamó wo àwùjo Yorùbá. Títí tí àwon èèbó wònyìí fi fún orílè èdè Nàìjíríà ní òmìnira, tí wón sí padà sí ìlú won. A kò gbó pé ilé ìfowópamó kan ní orílè èdè yìí dojúdé. Léyín òmìnira tí orísìírísìí ìwà ìbàjé wò àwùjo Yorùbá ni àsà owó kíkóje bèrè. Kò sí ìyàtò nínú omo ń féwó àti omo ń jalè. Òkan náà ni owó kíkóje àti olè jíjà.
Òpò àwon ògá ńlá ńlá òhún hu ìwà olè yìí nítorí pé wón mò pé orílè èdè yìí kò ní òfin tí ó le fi ìyà tí ó tó ìyà je àwon, bí owó ba tilè te àwon kò sí ètò pé kí á gba gbogbo ohun tí wón jí kó padà. Nígbà mìíràn, ofin le so pé ki òdaràn tí ó jí àádóta egbèrún san ìrinwó náirà gégé bi owó ìtanràn. Gbogbo ìwònyí ló jé ki ìwà òdàràn yìí gbilè bí òwàrà òjo. Èyí ló sì mu Orlando ké gbàjarè nínú orin. Léyìn òpòlopò odún tí Orlando ti korin ni ìjoba gbé àjo `Econonomic and Financial Crime Commission (EFCC) kalè. Àjo yìí lágbára láti pe eni ba kówó je léjó. Ó sì ni agbára láti gbésè lé owó tí ó jí tàbí dúkìá ti ó fi owó òhún rà. A wòye pé olè kò fi béè pò ni àwùjo àwon Hausa bí i ti ilè Yorùbá àti ìlè àwon Ìgbò. Ní àkókó, ètò àwùjo Hausa fi ààyè sílè fún títoroje. Àwùjo won ní ètò bí àwon olówó yóò se máa bó tálíkà. Tomodétàgbà ní í toro ni àwùjo Hausa. Lópò ìgbà orí ebi ni olè jíjà ti ń bèrè, kí ó tó di fóléfolé. Kì í se oúnje nìkan ni tomodétagbà lè toro ní àwùjo Hausa. Wón lè tòrò nnkan àlò mìíràn bí aso, bàtà, abbl. Ètò ìtoroje àti ìtore àánú tí ó wà láwùjo jé okan nínú ohun tí kó jé kí olè pò jù.
Bí a bá tilè wo orúko àwon olè tí won ti mi ìlú tìtì ní orílè èdè yìí, àwon èdá bi Oyèénúsì àti Lawrence Anini, kò sí omo Hausa nínú won, won kò sì fi ibùdó ìjalè won sí àwùjo Hausa.
Ní sókí olè wà ní àwùjo méjéèjì sùgbón osé tí wón ń se ní àwùjo Yorùbá ju ti Hausa lo. Ìdí nìyí ti Orlando fi ko o lorin tí Dan Maraya kò sì rí i bí i wàhálà kan pàtàkì.
Léyìn ti a ti wo apá kìn-ín-ní nínú orí kerin yìí tí ó je mo àwon èkó-ajemó-ìwà-omolúwàbí tí Orlando ménu bà sùgbón ti Dan Maraya kò sòrò bá. A ó wo apá kejì tí ó jé mo àwon èkó-ajemó ìwà omolúwàbí tí Dan Maraya ménu bà sùgbón tí Orlando kò ménu bà.