Idanilekoo Yemi Elebuibon

From Wikipedia

Idanilekoo Yemi Elebuibon

ÀDÀKO ÌDÁNILÉKÒÓ LÓRÍ ÈRÍ OKÀN TÍ A GBÀ SÍLÈ LÁTI ENU AWO YEMI ELÉBUÙBON-

ÀDÀKO LÁTI OWÓ OLÚSOLÁ ÀKÀNDÉ –

E sé o;

Wón ni osé náà ò se é tó báun

Lódòo Sàngó tó fi ń jósé

E kú ìpé gbogbo èyin ènìyàn an wa.

E kúu láéláé

E kú lànsèrán Omo asòkélà.

Ìpé tí a pé wònyí,

Ikú ò ní ré gbogbo wa

Lókànlókàn lo bí isu

Ègbà ò ní gba ire owó àwa dànù

Ilé ò ni lé wa,

Ònà ò ní nà wá

Gbangba òde ò ní gba wa lójú

Ìkònà tó burú ò ní kò wá

Bá a ti ń lo la ó máa bò,

A à ní se gégé ibi.

Alága ti so ohun tí òrò wa òní yóò dá le lórí. Won sì ni enì kan kò ní mójó so lókùn ilè ń sú. Tí a bá sì dé ibi isé ń se là á se é. ÈRÍ OKÀN ni wón pe àkolé òrò wa tòní. Gégé bí gbogbo wa ti mò pé Okàn ni n nnkan ti a fi ń mí. Bí a bá sì wò ó dunjú a o ri i pé, eranko lókàn, Àwa èèyàn papàá, a lókàn. A tún ní ìgbàgbó pé eye àti òpòlopò àwon nnkan míràn tí ó jé bí èmí àìrí, àwon papàá náà ni okàn. Sùgbón ohun tí a ń sòrò le lórí lónìí ni ÈRÌ OKEN ti àwa èèyàn, àní àwa ÈDÁ OMO OÒDUÀ.

Ohun tí a le pà ní èrí Okàn ni nnkan tí èdá ní tí ń jérìí sí nnkan tí ó bá se. Bóyá nnkan tí o dára tàbí nnkan tí ó burú tí a hùníwà. Nígbà tí a bá hùwà tó dáa, ara wa yóò yá gágágá. Sùgbón tí a bá hùwà tó buréwà ara wa a sì gògògò. Èyí ni gbogbo àwon Odù Ifá tí a máa ń rí fi tóka sí gbogbo ìse, ìwà àwa ènìyàn, eranko àti èmi tí a rí àti emi tí a kò rí. Kí n to wa máa bá òrò lo, n o kókó fi Odù kan se àpeere ohun tí a fé sòrò le lórí nítorí Ifá ni gbòngbò ogbón ìjìnlè ilè Yorùbá. Gégé bí ÒKÀNRÀN ÌROSÙN se wí nínú Odù u rè, ó ní;

Igi ńlá n ló tóbi nínú igbó

Nígbà ó tóbi nínú igbó

Ó nagò fàbìfàbì dinà.

Adíà fún Irókò Ìgbò

Níjó tí n be láàrin òtá

Adíá fún Odíderé

Níjó ti n lo Orí Ìròkó

lo rè é dúró sí.

Sé E rí Ìrókò Ìgbò, igi ni, Ààrin òtá ló ti wà télè. Láàrin aginjù, nínú igbó, won kò jé kí Ìrókò rí ònà mí.

Bóo lòun yóò ti se segun òtá

Báyìí:

Wón ní kí Ìrókò Ìgbò

Wón ní kó rúbo

Wón ni yóò ségun gbogbo òtá

Tó dìrò mó o, Tí kò jé kó rónà mí

Kínni kóun ó rú lébo

Wón ní kó ní àkùko Adie

Kó ní epo àti obì

Won se Ifá fún Ìrókò Ìgbò.

Nígbà tí ebo ó dà fún Ìrókò Ìgbò, ní àwon ará ìlú tí won ti wà légbèé ibè bá bèrè sí í sán igbó. Ìtí ni, ìtàkùn ni, Aagba to ti rò mó Ìrókò lórùn, wón bá bèrè sí gé won kúrò. Ni gbogbo ìdí Ìrókò bá mó fo. Ni Odíderé bá wá gbéra. Òun le ríbi wò sí. Odíderé náà, Orùn Ìrókò tóun ń lo yìí Òun lè ma ri ìfà je.

Won ni kí Odíderé náà kó rúbo

Kó rú eyelé, kó rú Òké Mérìndínlógún

Odíderé rúbo

Òun náà wà lo orí.

O lo rè é dúró sí.

Gégé bí Ìgbàgbó àwon Yoòbá. Tí àwon ìyálójà, bí won ba ti wá ń kójá lo nídìí Ìrókò Ìgbò yìí, eni tí ń tarú, eni tí ń tata, eni tí ń taso, won yóò wá máa wúre nídìí Ìrókò yìí. Won á ní:

Ìwo Ìrókò, jé n tà o

Jé n lówó o.

Jé n powó o.

Eni tí ó bá lo ojà. Nígbà tí ó bá ta ojà rè tán tí ń bò, á wá ìrèké, yóò jù ú sí ìdí Ìrókò. Elòmíràn le fi irú síbè, eni tí yóò fi ata béè. Orísìírísìí nnkan ló kún ìdí Ìrókò yìí. Sùgbón Ìrókò kì í sòrò.

Nígbà tí odíderé wá dé Orí Ìrókò, ló bá di pé tí won bá ti wúre:

Eni tó fe lówó

Odíderé yóò da lóhùn pé

O ó lówó, ó tàtàtà


O ó pegbèrún owó

Wón ní Ìrókò ńlá ma ni

Ìrókò yìí o.

Eni bèrè sí ní ya gbogbo ènìyàn. Eni tó fómo o bí, eni ojú ń pón, Òkìkì Ìrókò yìí bá bèrè sí kàn. Bí won bá sì ti wúre tán, Odíderé ni yóò dá won lóhùn lórùn igi. Gbogbo ìre tí won bá sì ti wú tán, béè náà ni ń rí.

Ó wá se ní ojó kan. Obìnrin àgàn kan, ó yàgàn ó fòpá ara tìí. Won ní kí ó lo rèé bò Ìrókò. Òun lè bímobáyìí. Won ní kí ó lo rèé toro gbogbo ohun tí ó bá wù ú lódò Ìrókò. Lobìnrin yìí wa lo sí òdò Ìrókò Ìgbò, pé kì ó fún òun lómo, òun yóò si fún on ni odidi eran.

Odíderé ní kó se. Ìrókò kò kuku le sòrò. Obìnrin yìí wá lo tán, l’Odóderé wá pé Ìrókò. Ó ní ìwo Ìrókò, Obìnrin tó wá toro omo yìío, ó ní yóò bímo. Ó ní ó sì ti sèlérí pé òun yóò mu eran wá o. Óní tí ó bá ti mu eran yìí dé, o ní Okàn rè ni kó fún òun. Gbogbo ohun tó bá rí ni kó fi ìyókù se. Ìrókò ní kò burú. Kí á má paá kí á má wo, Obìnrin yìí finú soyún, ó fi èyìn pòn. Ó sì wá jé èjé rè. Ó mú eran wá sí ìdí Ìrókò. Ó so eran yìí mólè.

Ní Odíderé bá wá ń béèrè Okàn lówó Ìrókò. Ó ní gbogbo ohun tí won kuku ti máa ń mú wá kò sí Òkankan tí òun ti máa ń béèrè níbè. Sùgbón OKÀN ni òun fé kí ó fún òun. Ha! Ìrókò ní nígbà tí o ò tí ì dé ìhín, n ni wón ti máa ń wá jé èjé ní òdò òun. Ní won sì ti máa ń mú nnkan èjé wá. Ó ní o ti se wa le dé ìhín kí o wá di òràn sí òun lórùn. Ó ní nígbà tí ajá fi ń selé, ó ní inú igbó lòbò wà. Bó ò bá sí lódò òun mó, o ni òun yóò maa se nnkan òun lo. Ha! ni Odíderé dá Ìrókò lóhùn. Ó ní báyìí kó lojú rí tí a fi ń jobì lójà Ede. Oò wá se wí báyìí fún òun télè wí pé o ò ni fún òun loken eran kí oun si ti mo télè. Njé o wa se é dáa báun. Ìrókò ni ‘òun se é dáa. Ó ní òun le se é bí ó ti rí. Ó wá ya nù-un, gbogbo àwon èrò ojà bí won bá tún ti de:

Ìrókò Ìgbò je n tà

Jé n lówó o.

Odíderé a ní:

O ò ní tà

a ló ò ní powó.

Ha! enì kínní béè, enì kejì béè Òkìkí bá kàn. Wón bá lo rèé bá Oba ní ìlú. Wón ní “Ìrókò kan tí ń mà ń be ní èbá esè ònà tí àwon máa ń gbà wá sí ojà, ó mà ti gbàbòdè, Ìrókò òhún máa ti ní nnkan míìrán nínú. Bí àwon bá mà ti dé ìbè, tí àwon bá ti wúre, èpè ni ń mà ń gbé àwon sé. Oba ni lóòótó? Ló bá pe gbogbo àwon ìjòyè rè. Ni wón bá kó ara won rierierie, ó di ìdí Ìrókò. Nígbà tí won dé ibè, Wón sàdúà pé:

Ìwo Ìrókò Ìgbò

Jé kí Ìlú yìí ó tòrò o

Má jé kí ìlú yìí ó bàjé ó

Jé kí ìlú yìí o rójú o.

odíderé ni:

E ó ma gbóná ni

Kò ní tòrò

Kò ní tuba

Ni Oba bá ní kò ní síse kò sí làise, won ni ki won wa gé Ìrókò Ìgbò. Ni wón bá kó àáké. Ni wón bá yo àáké ti Ìrókò Ìgbò. Bí won ti so àáké si Ìrókò O ni, ‘gbìn.’ Odíderé ni:

Torí Okàn

Torí Okàn

Torí Okàn

Béè ni won se wó igi Ìrókò. Nígbà tí Igi yìí yóò wó lulè, Odíderé ní;

‘Ilé alaseju hàngàngàn

Ilé alásejù wo hàngàngàn

Nítorí Okàn.

Àpeere kan tí mo wúwá láti inú Odù Ifá nìyìí. E ó ri wí pé Ìrókò Ìgbò kò ní èrí Okàn rè. Ó sì ní, sùgbón kò mu lò ní ònà tí ó le mú ki nnkan rere máa dé báa.

Béè wa ni o máa ń selè sí àwa ènìyàn. Bí a báa ń lo èrí Okàn wa sí nnkan tí ó dára, ara wa yó máa yá, nnkan rere yóò sì ma bá wa. Nínú èyí tí o sìkejì, ese Ifá tí a o tún gbón ni ti inú Ogbè ìyónu. Nínú ese Odù Ifá tí ó wí pé:

A gbá yàà

A tàn yàà

Petu ní se baba Òjé

Òjé ni se baba a petu

Ádíá fÓlórunkòlódúdú

Ó jí ni kùtùkùtù

N fomi ojú s’ogbere ire gbogbo.

Olórun kòlódúdú; à á se s mò ó ni à á pe ‘Òrúnmìlà.’ Sùgbón Olórunkòlódúdú ni Odù Ifá yìí pè é. Ojú owó bere sí pón on. Ó wá owó, ko r’ówó. O wa gbe Oke ìpònrí re kalè. Òun le là, kóun o lowo? Kóun o nilaarin báyìí?

Wón ní kó rúbo

Wón ní kó rú Eyelé Èjìgbèdè

Tó jé mérìndínlógún

Níbi ti won bá gbé je tiiri

Wón ní kó ní Ìgbín

Wón ní kó ní gbogbo nnkan

Ni mérìndínlógún mérìndínlógun.

Ó wá wá gbogbo àwon nnkan wònyìí títí. Kò sí ní òde ìsálayé yìí níbi tí won gbé rí eyelé èjìgbedè tí ó jé mérìndínlógún tí ó jé pe ìyá kan náà ni ó pa wón. Ní Olórunkòródú bá gbé awò ò rè. Ló bá wò gbogbo àyíká. Ó ri pé kò sí ibi tí òun ti le rí Eyelé Èjìgbèdè lékùlé Olódùmarè níbi tí won gbé jé tiiri! Ló bá wá gbéra, ló bá lo. ìwo Olódùamrè fún oun ní eyelé èjìgbèdè èjìgbèdè báyìí báyìí, wón ní kí o oun o se Ifá báyìí báyìí……………….

Olódùmarè ni kí o máa ko won lo. Ló bá ko eyelé yìí wá sí ilé ayé. Ni wón ba se Ifá fún un. Àwon babaláwo ní kí ó máa kó méjo lo. Méjo yìí ni ó wá ń sìn gégé bí nnkan òsìn rè. Àti ìgbà tí ó sì ti ní sìn ín in ó ti rí i pé àyípadà ti ń dé ba ayé òun. Ìgbà tí ó di ojó kan, sálálá èyí tí í se òkan nínú àwon ajogun ìránsé Olódùmarè, ló bá bèrè sí í sòjòjò, ó wá jé omolójú Olódùmarè. Àwon babaláwo bá tún dÁfá. Wón ní Eyelé Èljìgbèdè, wón ní ibi ti won bá tún gbé jé tiiri, wón ní ibè ni kí won o tún lo rèé wa won wá. Wón tún wá eyelé lóde òrun, won ò rí. Èkùlé Olórunkòlódúdú, ibè ni wón ti ri eyelé. Ni Olódùmarè bá rán àwon ikòo gbènúgbènú, ó ní kí won ó lo kó eyelé òhún wá. Olórunkòlódúdú kò sí nílé, won kó eyelé lo.

Nígbà tí Olórunkòlódúdú darí dé, ó wo ilé rè. Kò bá eyelé nílé mó. Èyin Obìnrin yìí, èétirí? ta ló wo ilé wa tí ó kó eyelé lo? Wón ní àwon kò mà rí irú ikò òhún rí O. Won ní bí won ti ń balè soorosà báyìí náà ni wón sì ń kó eyelé lo. Olórunkòlódúdú ko béèrè mó. Ni ó bá gbé àpèrè aye ònwò rè. Ni ó bá bèrè sí na ikò sóde òrun, ló bá fòn ón, ni ó bá ń lo. Ibè ni gbogbo àwon apètèbí re bá bèrè sí fi iyèrè sohùn arò, wón mékún won fi digbe. Wón ń wí pé:

Háráhárá balé ó kú harahara

O dáké ilé ni

Òdidè babá ń béye é rà á lo

Òdìdè

Èjò balè fi gbogbo ara lóńkulònku

O dáké lé

Òdìdè babá ń béye e rà á lo

Òdìdè.

Òrúnmìlà ò dá won lóhùn. Ó dá Òrun. Ìgbà tí ó dé iwájú Olódùmarè ló bá ko ejó, ló bá ni ìwo Olódùmarè nítorí kí tòun ó lè baà dáa ni wón se ní kí òun ó “ní eyelé Èjìgbèdè níbi tí won gbé jé tiiri.” Òun sì rúbo náà tán. O tún ní kí won o wá kó eyelé Èjìgbèdè náà. O ó ba tòun jé ni Olódumarè loun o bá tie jé. Ohun tí o selè nìyìí. Emi ló wa le tó béè. Ó ni:

Óun ń sunkún owó

Òun ò lówó

Òun ń sunkún ire gbogbo

Òun ò ríre gbogbo.

Olódùmarè wá ní gbogbo àwon ikò tí Olórunkòlódúdú ń fi nnkan rán ó ní won ò kó nnkan ebo jísé. Ó ní nígbà tí won bá dé Ojà Olòrun, ó ní níjó tí won ní kí

Ó fi o eku mérìndínlógún rúbo

Ó ní bí òun se ń wò ó nìyí. Ó ní sùgbón won ò kó àwon nnkan ebo náà de iwájú òun. Ó ní bí àwon Alórí-má-lésè Alésè-má-lórí. Ó ní bí won ti rí won tí won réku lówó omo eléku. Wón bi í wí pé

Omo eléku jòó èló ni o fe tàá

Ni o bá gbowó lówó won, Ó kéku fún àwon tí ó jeku.

Lójó tó kéku wá béè

Níjó tó kéye wá béè

Ó ní gbogbo ohun tí Òrunmìlà ti se ló jé kí wàhálà rè ó pò. Ó ní òkóòkan won ò mú f’óun. Òrúnmìlà ní gbogbo àwon tí òun fi kinní yìí rán, àwon omo awo òun ni. T’óun sì ti gbé Okàn lé won pe. Etì ò le yèé. Àwon náà ni yóò ko nnkan wònyìí jísé. Olódùmarè wá ni kí Olórunkòlódúdú, kó bó sí èhìkúlé òun, ó ní yóò ri ibùsò egba ènìyàn níbè. Ó ní kó já ewé re, ó ní tó bá délé kó gún un móse. Olórunkòlódúdú bi í léèrè gbogbo ohun ti yóò fi se àkóso náà.

Ìgbà tí Olórunkòlódúdú darí wolé, kò sí àwon Apètèbí rè kankan nínú ilé. Ogbón ti Olódùmarè kó o, ogbón náà ni ó ń se, njé o, ó hà ti rí

Baba pèlé

Baba ò se kúkú tí í mérin ín fon

Ògùngùn ti i gorí ìjímèrè

Kórí ìjímèrè o maa baà kú tán.

Hàáà! ni Òrùmìlà bá mú ekún ó fi dígbe. Ó ní:

Háráhárá balè ó kú háráhárá

Omo awo mi kò jísé

Ebo mi lorun

Ènìyàn, èèyàn rere ma won o

Ènìyàn

Ejò balè se gbogbo ara se

Lóńkulònku

Omo awoò mi

Ò jísé ebo mi lórun

Ènìyàn rere mà wón O

Ènìyàn

Gbogbo omo awo ni kò jísé

Ebo mi lórun

Ènìyàn, Èèyàn mà wón o

Ènìyàn won mo bá fò lulè

Òrúnmìlà bá ni kí won má bá òun leere ohun tí yóò selè. Ó ní gbogbo àwon tí òun ti fi Okàn tán, ó ní won ti mú ayé òun dòlolombo. Ni Òrúnmìlà wa ni ki won lo rè é ránsé sí gbogbo won wa. Àwon Amósù, Àwon Dòpèmu, àwon háráhára balè ó kú háráhárá. Èrí Okàn ó ti mú wòn. Gbogbo won ni wón ń sa bùjebùje, won o le dé ilé Oba elésin mó. Béè ni won o le dódò baba àgbà gbáà Okòrì.

Nínú àpeere ìtàn yìí, ó fi han wí pé tí ènìyàn ba se rere, ara yóò ya. N náà ni Ifá so, ó ní:

Tí a bá jí láàárò

Tí a bá hùwà rere

Ara eni a máa yá gágágá

Tí a bá pàdé Obun resuresu

Lójú ònà

À sì pa rèsùrèsù

A wè róró

Lolorun yan waye.

Gégé bí Olórunkòlódúdú se se sí àwon omo awo re lójó náà. Ó ní eni tí ó bá le ko òun lójú, tí ó jé pe Okàn rè mó délè, ó ní n ni ki won o wa jéwó.

Nítorí pé nígbà tí òrò náà kètí tán, wón bèrè sí í yan elèbè. Gbogbo àwon àgbààgbà ni wón bèrè sí í yàn sí Òrúnmìlà. Won sìpèsìpè. Sùgbón Òrúnmìlà ní àfi kí won wá fún ara won. Àwon náà ni wón le sipe ara won. Nítorí náà, nínú àpeere kókó òrò tí a ń bá lo. ÈRÍ OKÀN a má jéèyàn nígbà tí a bá hùwà búburú Gbogbo wa ni à sì ní èmí pé tí a bá hùwà rere a ó rí rere gbà. Ti a bá sì hùwà búburú a ó fé bèèrè fún ìdáríjì nítorí kí buburú ma se bé wa. Èyí ni a ki rí kó nínú Ogbè-Ìyónú yìí:-

Eléyìí ni n ó fi se eketa nínú kókó òrò tí a ń bá lo lónìín nítorí pé à ó rójó so lókùn. Odù náà ni ti Ogbè ìwèhìn tí ó so pé:

Bínú se gbá

Babaláwo ahun ló kifá fáwun;

Bínú ò se gbá

Babaláwo Ogbè ló kifá fógbè

Àwon méjèèjì

Wón jo ń sòré ìmùlè papò


Ojú Odù yìí ló dá òwe àti ìtàn tí gbogbo àwon ènìyàn máa ń pa pé “inú ò bá se ‘gbá, à bá sí i wò.” Torí pé eni tí a bá ń léku sí, ti ó léjò sí ni, à á fi í sílè ni. Sùgbón eni tí ń tan ni ló gbón ju ni lo. Eni tí a ń tàn ni ò gbón.

Nígbà tí a bá so pé, èmi tí mo jókòó yìí, o, èèyàn an re ni mí, nígbà tí e gbó ohùn enu mi, sùgbón e kò mo nnkan tí o wà ikùn mi. Béè ni ti Ogbè ìwèjìn se rí:

Bínú se gbá

Babaláwo awun ló kifá fáwun.

Wón ní gbogbo ogbón, ètekéte, èròkerò tí alábawun máa ń fé lò, wón ní lédún yìí o, wón ni kó wa owó re bolè Wón ní ogbón àdájopín ni Alábawun ń dá. Alábawun ní ojó tí òun ti ń dábàá yìí, enìkan kò dí òun lówó rí:

Bínú ò se gbá

Babaláwo Ògbe ló sefá f’Ógbà

Ogbè nìyí Òré alábawun ni. (Ogbè tí a ń dárúko yìí ni Òkan lára àwon Odù Ifá ni. Nígbà kan òun wà gégé bí ènìyàn (àsìkò náà). Gbogbo òrò tí Ogbè bá ní lókàn ni o máa ń so fún alábawun. Ó sì jé eni tí mo ode í se. Ó lóògùn, ó sì gbówó. Sùgbón òrò kan ni Ogbè yóò wí, méèédógbòn ni alábawun ó fi máa pè káàkiri.

Ìgbà tí yóò se, ni ojó yìí, ni Ogbè bá pe Òré re, ó ní òun fé lo sí ègùn Òwúrò. Ó lóhun Ó lo rè é dègbé àdàmójú. Abaun ní torí irú eran èwo wa nù un. Ó ní bí òun bá r’ékùn, ó ní bí òun ò bá si rékùn, ó ní eran tí òun ba kó rí pa, n náà ni òun yóò máa ba bò wá sílé. Òun ò ní pé:

Ní alábawun bá gbéra pá, ó dilé Oba, ó bá lo wí fún Oba Àjàláyé. Ó ní:

“Ogbè tí è ń wò un

Ode mà ni.

Gbogbo àwon ará ìlú ba so pé àwon mò pé Ode ni. Àwon ti ń gbúró rè ojó ti pé. Ó ní “ohun tí Ogbè wá wí fún òun lónìí nù un nítorí Òré òun tímótímó ni. Ó ní ó so pé òun le mú ekùn láàyè.

Oba ni “béè tó o “wí”. Ó ní “béè ni.” Ó ní “O lóògùn, ó gbówó débè, òògùn tó sèsè se, ń ni ń tì í béè.” Oba bá ní kí won ó ránsé sí Ogbè, kí wón ó pè é wá.

Ni Alábàwun bá lo pe Ogbè pe: “iwo Ogbè, Oba lóun ní isé tí òun fé yàn fún o. Bi o bá le jé isé náà, òun yóò dá ilé òun, ònà òun, òun yóò fi jìn o. Àmo tí o kò ba le je, Ojú re ni òun yóò ti yodà, èyìn re ni òun yóò fit ì í bò ó àkò.” Ogbè ní “isé wo wa nù un”. “Alábawun ní “Obá ní kí o lo mú ekun wá láàyè fún òun. Ogbè o le kò, kò sì le jé e.

Ará bèrè sí í tì í. Emi ló tó se èyí. Ara lílò lo ba lo sí ilé rè. Ó ro òrò náà, kò jáa. Ló wá mú eéjì ó fi kún eétan, n ló bá ké sí babaláwo rè.

‘Bínú ò se gbá’

Kó ye òun lóókàn ìbò wò pé isé ti Oba gbé ka òun láyà yìí, òun ó se le yorí níbè tí oun ò ní se é tì.

Wón ní kí Ogbè ó rúbo

Wón ni ki o ma ma fi gbogbo

Òrò rè,

Wón ni ki o ma ma so ó

síta mó.

Won ni enìkan tí kò jìnnà sí i

tí ó sunmo on

Ní ń se ènìní rè.

Wón ní àmó ti o ba wá

le rúbo o

Wón ní yóò ségun rè.

Wón ni eni tí ń sènìní

Re náà ni yóò ran an lówó

Ní Ogbè pòpáború, rírú lo rúbo.

Ìgbà tí o rúbo tán, ó wá gbéra ó di inú igbó. Kò kúkú sí ègùn tí ó le fi mú ekùn láàyè. Ká sode, ká peran náà lo mo mo.

Èsù wa lo di àgbó

Mo lo di àfàkàn

N won lo di Òkeere

Opin Onà sún

N jé tà ló sun kàn

Won ní alabawun àti Ogbè ni

Ta ló rú, Ta ni ó rú

Wón ni Ogbè ló rú.

N ni Èsù ba so ara re di ènìyàn, ló bá ké sí. Ogbè, ó ní kí o máa kálo. Ó ní oun mo ibi ekun wà. Sùgbón ó sèsè bímo ni. Ó ní tí ó bá fi le lò ó, ó ní yóò gbé omo ekùn láàyè, ó ní yóò sì gbé e dé iwájú Oba.

Ló bá gbé àdó ìsújú rè, ló bá gbé e fún Ogbè. Ni Ogbè bá gbé àdó ìsújú náà, ó nà án sí ekùn. Ní ekún bá fi omo rè sílè, ló bá lo, Yànyán-nse tí ekùn ń se káàkiri ìgbé, ni Ogbè àti Èsù de ibi tí omo Ekùn wà. Ni wón bá gbé omo kan. Ìgbà tí won gbé omo yìí, ló bá di rierierie.

Sùgbón àpeere kan ń be tí Olódumarè ti fún ekùn. Bí nnkan kan bá ti selè ńse ni omú rè o bèrè sí í sè pèrèpèrè. Ó ti mò pé nnkan se àwon omo òun nù-un. Ibi tí ekùn wà, níbè ni omú rè ti bèrè sí í sè pèrèpèrè. Ha! ó ní ènìyàn dé ibi omo òun. Ni ó bá faré sí i. Ó di rererererere. Kí won ó wolé Oba báyìí, ekùn dé ibi tí ó kó àwon omo rè sí, kò bá omo kan. Ha!, ó bá bèrè sí fimú fínlè, ònà ibi tí won gbà lo ni ó bá fòn ón.

Ìgbà tí Ogbè dé iwájú Oba Àjàláyé tí ó gbé omo ekùn kale, pé kábíyèsí, isé té e rán mi ni mo jé yìí o. Níbè ni alábawun Àjàpá ti ń to ipasè rè bò. Ekùn pàdé rè lónà, ó sì béèrè pé tani ó gbé òun lómo. Ó ní kó se òun jééjé. O ni ‘òun mo ilé eni tí ó gbé omo rè.” Ni ekùn ba tèle Alábaun Àjàpá. Nígbà tí won yóò dé ilé Ogbè, won ò b’Ógbè nílé. Ó ti lo sódò Oba. Won sì tì kilo f’Ógbè wí pé ibi ti ó bá gbà wo ààfin Oba kí ó má gba ibè jáde mó. Pé tí ó bá gba ònà èbùrú wolé, kí ó gba ojúlé ònà padà jáde. Bí ó bá sì gba ònà ojúùle wolé, kí ó gba ònà èbùrú jáde. Kò pé, ekùn wo ànfin. Wón bi í wí pé emi ló dé. Ó ní òun ko rí omo òun. Àbí kín ló bá òun kómo òun nílè. Òun sì pàdé alábaun Àjàpá lónà ó ní òun mo eni tó gbé e. Àwon sì délé Olúwa rè àwon ò sì báa. Ó ní haa!, ó ní e ò le báa mó. Ó ní o ti tún mórí lénú igbó. Ni Èsù bá na àdó àtibi rè, o náà sí ekùn. Ni ekùn bá tún mórí lénú igbó. Ó ní tí ó bá dúró láàrin ìlú yìí, ó ní apó, ofà ni àwon omo ènìyàn ìlú yìí yóò yo síi. Ó ní kí ekùn máa gba ààrin ìgbé lo. Ni ekùn bá sá lo. N ni Èsù bá ní ki alabawun kí ó kálo sódò Ogbè, ó ní nítorí pé Oba tí ó pè é, Oba ti mú ilé, ó ti gbé e fún un. Erúkùnrin, Erúbìnrin.

Haa! Alábawun ní òun ò le dódò Ogbè. Ó lórèé òun ni lóòótó, ó ni sùgbón òun kò le dódò rè. Èéatise, ó ní òun ò le débè mó. Nítorí kínní, nítorí kínní, nítorí èrí Okàn. Èri Okàn alábawun kò jé kò le dódòo Ogbè.

Nínú ìtàn ti Ogbè ìwèhìn fi ń ko wa yìí. A rí i wí pé gbogbo nnkan tí a sabáà máa n rí nígbà tí a bá se rere, ara wa ó yá. Sùgbón nígbà tí a bá hùwà òmùgò, ń se ni ara wa o maa ló tìkòtìkò. Nitori náà, gégé bí òrò tí a ti ń so bò látòní, ÈRÍ OKÀN ni nnkan tí ń jérìí sí nnkan tí a se ni rere tàbí ní buburú. Sùgbón ní gbogbo àbálo àbábò tí a ti rí, mo ro gbogbo èyìn olùtétí tí a jo wà níhìnín pé kí a máa se rere. Kí a má baà máa kábámò, kí ara wa kí ó le máa yá. Àìní ÈRÍ OKÀN ló mú kí òpòlopò o máa hun ìwà buburú tí a ń rí lóde òní.

Tí a bá ń rí èrí Okàn máa jé ni lérìí pé nnkan tí à ń se yìí pé kò dára. Bí ènìyàn kò tilè sí níbè, a ó máa síwó kúrò níbè. Kì í se ìgbà tí a bá rí ènìyàn táa bá ń se rere nìkan. Nígbà tí ènìyàn kò rí ni, ti a sì ń se rere. Ohun ni ìgbà tí a gbà pé èrí Okàn wa pèlú eni tí a si ń mú un lò.

E kú ìpé o, E kú ìkàlè