Ede Yoruba
From Wikipedia
ADEYEMO AKINLOYE STEVE
EDE YORUBA
Orílè-èdèe Yorùbá jé àti-ìran-díran odùduwà pèlú gbogbo àwon tí ń sin olórun ní ònà tí odùduwà ń gbà sìn-ín, tí wón sì bá a jáde kúrò ní agbedegbede ìwò oòrùn nígbà tí ìrúkèrúdò dé nípa ìgbàgbó rè. ÈDÈ YORÙBÁ: Nínú èdè Hausa “Yarabawa” dúró fún Yorùbá, “Yarabanci” sì dúró fún èdè Yorùbá. Nínú èdè Heberu, a rí “Yareb” àti “Yariba” àti “Yi oharib”. Títí di odún 1787, kò sí orúko kan tí a fi ń pè àwon Yorùbá lápapò. “Aku” ni wón ń pe àwon tó wá sí sàró léhìn òwò erú. Won kìí gbà kí wón pè wón ní Yorùbá. Àwon òyó nìkan ló gba orúko yìí ní orúko àpapò nígbà tí òlàjú dé. Ní odún 1917 ni òyìnbó ajélè kan gba àwon èyà yòókù níyànjú láti ka ara won kún Yorùbá kí á sì mò wón ní eya kan náà pèlú àwon ara òyó. Tí a bá wá wo èdè Hausa, èdè Heberu àti àwon èdè míràn, a lè so wípé “Èdè jé ònà bíbá ara eni sòrò ní oníran-n-ran tó sì jé pé orísìí kan yàtò sí òmíràn gédégédé. Bí a se ń so èyà èdè kan yàtò sí òmíràn. Èdè máa ń yípadà, òun sì ni esin tí “àsà” ń gùn ‘kútúpà kútúpà’. Èdè Yorùbá jé èdè abínibí àwon omo ilè káàárò o-òjíire bíi ìpínlè Èkó, Ògùn, Òyó, Kwara, Òndó, Kogi àti apá kan ìpínle Edo. Òpò ni àwon tó ń so o ni Togo, Ghana àti sàró (Sierraleone). Wón ń lò ó ni Brazil, Cuba, Jamaica, Trinidad, Tobago àti àwon erékùsù Caribbean. Òun ló sìkejì èdè tó se pàtàkì jùlo ní orílè èdè Binni (Benin Republic). Ó pèka púpòpúpò. Láti inú èka èdè wònyí ni a ti yo olórí èka èdè Yorùbá. Bí àpeere: ìró nínú èka èdè - òwò máa ń lo [gb] dípò /W/. Ondó máa ń lo [h] dípò /r/= Òrò-Ohò. Ìjèbú rémo máa ń lo [gh] tàbí [v] dípò /W/= ìwo = Ugho; Wá níbí –Va n be!. Èkejì, a rí òrò nínú èka èdè - Ìkàré máa ń pe [Oó] dípò /Owó/. Ìbàràpá máa ń pe [aláàmó] dípò/alángbá/. Ìjèbú/Ègbá/Ìgbómìnà máa ń pe [dede/gedegede] dípò/gbogbo/. Èkéta tí ó dàbí rè ni Gbólóhùn nínú èka èdè- Àkókó, Èkìtì máa ń so pé “O ò gbudò lo” dípò “O ò gbodò lo”. Ìjèbú máa ń so pé “Bosí” dípò “Níbo”. Ègbádò máa ń so pé “Ibi sí"dípò “Níbo”. Ègbádò máa ń so pé “Ibi sí” dípò “Níbo”. Ohun tí a mò ní pàtó ni wí pé: Oyèníran (1976) pín èka èdè Yorùbá sí ònà mérin WY, SEY, CY, NEY. Adétugbò (1973) pín èka èdè Yorùbá sí ònà méta NWY, SEY, CY.
ÌTÀN ÀKOÓLÈ YORÙBÁ:
Ònà méjì ni a ó gbà fi wò èyí - Ònà kìíní ni ‘Ìtàn Yorùbá’. Ònà kejì sì ni ‘Àkoólè Yorùbá’. Òpòlopò Ìtàn ni ó ti wáyé lórí ibi tí Yorùbá sè wá. Iròyìn yìí yàtò sí ara won sùgbón gbogbo won gbàwí pé ń se ni Yorùbá sí láti àríwá ìlà-oòrùn wá sí ibi tí wón tèdó sí nísisìyí. Dr. Johnson so wí pé ilè ijibiti ni Yorùbá ti sè wá. Ó fi Nimrod oba Ijibiti tó rin ìrìn-àjò omo ogun lo sí ilè Arabia láti fi se ibùgbé sùgbón tí wón lée nítorí ìjà esin. Dr Luca fara mó èrò Johnson nípa títóka sí àwon èdè Yorùbá àti ti Ijibiti tí ó papò tàbí jora.
AKIYESI:
Dr. Biobaku àti àwon egbé rè tako èrò. Dr. Lucas lórí èdè Yorùbá àti ti Ijibiti tí ó jora. Ó ní só seé se kí èdè papò nípa òwò. Ó ní à ti pé Dr. Lucas ti pón èrò rè ju bí ó ti ye lo. Dr Idowu fi èrò tirè hàn pé Olódùmarè ló rán odùduwà wá ní àsìkò ti gbogbo ayé kún fún omi. Odùduwà da iyanrìn tí olódùmarè fun láti òrun sí orí omi, eyelé wá tàn-án yíká, odùduwà àti ènìyàn mérìndínlógún wá sòkalè sí Ilé-Ifè tí ó jé orírun Yorùbá. Nígbà tí ó yá àwon Ìgbò bèrè sí fi ara hàn wón gégé bí iwin/òrò nípa dída imò òpe bora láti máa yo wón. lénu. Léyìn ìwádìí lódò òrìsà, Moremi (arewà obìnrin) yònda láti bá àwon Ìgbò lo sí ìlú won. Èyí mú kí ó ri àsírí àwon Ìgbò, ó wá padà wá láti tú àsírí náà fún àwon ènìyàn rè. Ó wá mú omo rè kan soso “Olúorogbo” láti fi rúbo sí àwon òrìsa fún èjé tí ó jé. Èrò àwon tí ó se àtúnpalè Bíbélì láti èdè Oyìnbó sí èdè Yorùbá ní nnkan bíi èéégbèwá odún (19th century) ni pé ‘àsà’àti èrò inú àwon Heberu kò yàtò sí ti àwon Yorùbá Nínú òpòlopò ìròhìn, a lè pinnu láìsiyèméjì pé àwon Yorùbá láti ibi kan wá sí Ilé-Ifè ni. Bíi èédégbèrin odún sí èédégbèfà odún ni a gbà wí pé ó jé àsìkò tí Yorùbá sí láti ibìkan wá sí Ilé-Ifè. Dr. Biobaku, léyìn òpòlopò ìwádìí rè gbà wí pé nípa àtìleyìn àwon omo Ijibiti, Heberu àti àwon kan ni odùduwà àti àwon ènìyàn rè fi dé ibi tí wón fi se àtìpó ní nnkan bíi èédégbèrin odún pèlú àkójopò òtòòtò. Adémólá Fasiku fara mó èrò Dr. Johnson sùgbón Professor J.A. Atanda tako èrò yìí, ó ní apá ìwò oòrùn ni odùduwà àti àwon ènìyàn rè ti wá. Bákan náà wón ní ìjà èsìn tó mú kí Odùduwa ní kí wón pa omo rè Bùráímò elésìn Mùsùlùmí ni ó múu sá kúrò ní ìlà oòrùn láti wá tèdó sí Ilé-Ifè níbi tí ó ti bá Àgbonmiregun (sètílù-onífá) pàdé. Lára nnkan tí wón kó dé Ilé-Ifè ni ère méjì àti àlùkùránì fún bíbo. Àwon kan so pé Òkànbí nìkan ni Odùduwà bí, àwon kan ni béè kó pé omo mérìndínlógún ni, àwon kan tún so pé méje ni. Ìtàn tí ó wá so pé Òkànbí ni ó bí omo púpò, pé méje sì ni, ni enu kò lé lórí jùlo - Olówu, Alákétu, Oba biini, Òràngún Ilé-Ìlá, Onisabe ile sabe, Olúpópó oba pópó, Oranyan ti Òyó Ilé. Ju gbogbo rè lo bí èyà kan se se àti bí wón se bá ìrìnkèrindò won dé ibi tí wón wà lónìí kò yé enikéni. Ìgbàgbó wa ni pé omo odùduwà ni gbogbo wa àti pé Ilé-Ifè ni ati sè wá. Ìsesí, Ìhùwàsí, àsà àti èsìn wa kò yàtò. Lónà kejì, àwon onímò Lìngúísíìkì se àkoólè Yorùbá Bowdich ati Clapperton lo kókó gbìyànjú kíko òrò Yorùbá sílè. Akitiyan àkókó láti gbé ìlànà àkotó Yorùbá kalè wáyé láti owó J.B. Raban (1830-1832). Akitiyan yìí ran Ajayi Crowther, Gollmer, M.D’Avezac lówó láti se àtúpalè èdè Yorùbá. Eléyìí mú kí ìjo. C.M.S. níbi tí Raban ti jé ajíhìnrere pàsè lílo èdè Yorùbá nínú ìsìn ní 1844. Ní 1824 – 1830 Hannah kilham se ìbèwò sí ìwò oòrùn Áfíríkà léèméta lórí kíko àkoto tó rorùn, tó sì já gaara. Ní 1875 asojú gbogbo ìjo pe ara won jo láti fi enu kò lórí ònà kan soso tí won yóò máa gbà ko Yorùbá sílè. Lára àwon kókó náà nìwònyí:
(i) Lábé, o, s, ìlà kékeré ni kí á fà, kì í se kíkánmo sí nídìí
(ii) ‘gb’ kìí se ‘bh’ tabi ‘b’
(iii) P (kì í se ‘kp’)
(iv) Àtòsílè àwon òrò tí wón ní édà èka-èdè, U tàbí O nínú ìró àrańmúpè. O dúró nínú àbàwón; U nínú àdánù.
(v) Òfin lílo àmì-ohùn
ÀKOSÍLÈ TI O N SO NÍPA ORIRUN YORÙBÁ
Aáyan àwon onísé ìwádìí láti topinpin àwon Yorùbá ló gbé wa lo sínú àkosílè tí ó kókó ménu bà èyà Yorùbá. Irú àkosílè béè ni a gbó pé ‘Sultan Bello’ tíí se eni tó te ìlú sokoto dó, ko sílé ní èdè Hausa. Àkosílè yìí ni Captain Clapperton nínú isé Sultan Bello tí í pe àkolé rè ní “History of the Sudan”. Sultan Bello so báyìí nípa àwon Yorùbá, pé àwon èyà tí ń gbé ní agbègbè (Yarba) jé àrómódómo omo kénáànì, tí í se èyà “Nimrodu” ó tè síwájú láti so fún wa pé ohun tí ó sín won dé ìwò oòrùn Afirika ni lílé ti Yaarooba tí í se omo Khanta lé won kúrò ní ilè Arabia sí ààrìn ìwò oòrùn láàrin ilè ifibiti si Abyssiana, àti agbègbè ibè wón tí wo ààringbùngbùn ilè Afirika wa tótí won fi i tèdó sí ibi tí won fi se ibùdó báyìí tí a mò sí ilè Yarubá èyí ní Yorùbá. Nínú ìrìn àjò won, won a fi èyà won sílè ni ibikíbi tí wón bat i dúró. Ìdí nìyen tí a fi gbà pé àwon èyà ‘Sudan tí ó ń gbé ni orí òkè orílè èdè jé èyà àwon omo Yorùbá. Ohun ti àkosílè yìí ń so ni pé ó se é se kí ó jé pé lára àwon èyà tí a mò sí Yorùbá lónìí ni ‘Sultan Bello’ ń tóka sí nínú àkosílè rè.
ÀSÀ YORÙBÁ:
Àsà ni ohun gbobgo tó je mó ìgbé ayé àwon asùwàdà ènìyàn kan ni àdúgbò kan, bèrè lórí èrò, èdè, èsìn, ètò ìsèlú, ètò orò ajé, ìsèdá ohun èlò, ìtàn, òfin, ìse, ìrísí, ìhùwàsí, onà, oúnje, ònà ìse nnkan, yíyí àyíká tàbí àdúgbò kòòkan padà. Pàtàkì jùlo èsìn ìbílè, eré ìbílè àti isé ìbílè ni a lè pè ní àsà. Ohun ti o je orírun àsà ni ‘àrà’, ó lè dára tàbí kí ó burú. Ìpolówó Èkìtì – iyan rere, obe rere; Ipolowo Ondó Ègin – (dípò Iyán) èbà gbon fee. Àsà Ondó ni kí wón máa pe iyán ni èbà nítorí pé èèwò won ni, won kò gbódò polówó iyán ni àárín ìlú. Àsà je mó ìgbàgbó àpeere; àbíkú, àkúdàáyá. Àsà je mó isé onà ti a lè fojú rí tàbí aláfenuso. A lè pín àsà sí ìsòrí méta èyí tí ó je mó:
(a) Ogbón ìmò, ète tàbí ètò tí a ń gbà se nnken, àpeere ilà kíko, irun dídì abbl.
(b) Isé onà bíi igi gbígbé
(d) Bí a se ń darí ìhùwàsí àwon egbé/èyà kan
Ara àbùdá àsà ni pé: Kò lè súyo láìsí ènìyàn; èmí rè gùn ju ti ènìyàn lo; Ó je mó ohun tí a fojúrí; Àsà kòòkan ló ní ìdí kan pàtó; Àlàyé wà nípa àsà. Àsà lè jeyo nínú oúnje: Òkèlè wó pò nínú oúnje wa. Àkókó kúndùn èbà, Ìlàje-pupuru, Igbó orà-láfún. Àsà lè jeyo nínú ìtójú oyún/aláìsàn/òkú; ètò ebí/àjosepò; ètò ìsàkóso àdúgbò, abúlé tàbí lara dídá nípa isé onà. Bí ó tilè jé pé àsà máa ń yí padà nípa aso wíwò, ìgbeyàwó abbl lóde òní ètò èkó àti ìwà òlàjú tó gbòde kan ti se àkóbá fún àsà ní ònà yìí:
(a) Ìwoso wa kò bójú mu mó
(b) Àsà ìkíni wa kò ní òwò nínú mó
(d) Kí’yàwò ilé má mo oúnje ìbílè sè mó
(e) A kò mo ìtumò àrokò tí a ń kó àwon omo wa mó.
Àwon ònà tí àsà máa ń gbà yí padà nì wònyí:
(a) Bí àsà tó wà nílè bá lágbára ju èyí tó jé tuntun lo, èyí tó wà télè yóò borí tuntun, àpeere aso wíwò.
(b) Àyípadà lè wáyé bí àsà tó wà nílè télè bá jé dógbandógba pèlú àsà tuntun, wón lè jo rìn papò, bí àpeere àsà ìgbéyàwó.
(d) Bí àsà tuntun bá lágbára ju èyí tó wà nílè télè, yóò so àsà ti àtèhìnwódi ohun ìgbàgbé, àpeere bí a se ń kólé. Tí a bá wá wò ó fínnífínní, a ri wí pé àsà lópòlopò ìtbà máa ń dá lé:
(a) Ìmò isé sáyénsì
(b) Ìse jeun wa
(d) Ìsowó kólé
(e) Isé owó ní síse
ÀKÍYÈSI:-
Èdè àwon ènìyàn jé kókó kan pàtàkì nínú àsà won. Kò sí ègbón tàbí àbúrò nínú àsà àti èdè. Ìbejì ni wón. Ojó kan náà ni wón délé ayé nítorí pé kò sí ohun tí a fé so nípa àsà tí kì í se pé èdè ni a ó fi gbé e kalè. Láti ara èdè pàápàá ni a ti lè fa àsà yo. A lè fi èdè Yorùbá so ohun tó wà lókàn eni, a lè fi korin, a lè fi kéwì, a lè fi jósìn àti béè béè lo. Láti ara àwon nnkan tí a ń so jáde lénu wònyí ni àsà wa ti ń jeyo. Ara èdè Yorùbá náà ni òwe àti àwon àkànlò-èdè gbogbo. A lè fa púpò nínú àwon àsà wa yo láti ara òw àti àkànlò èdè. Nítorí náà, èdè ni ó jé òpómúléró fún àsà Yorùbá àti wí pé òun ni ó fà á tí ó fi jé wí pé bí àwon omo Odùduwà se tàn kálè, orílè-èdè kan ni wón, èdè kan náà ni wón ń so níbikíbi tí wón lè wà. Ìsesí, ìhùwàsí, àsà àti èsìn won kò yàtò. Fún ìdí èyí, láísí ènìyàn kò lè sí àsà rárá.
REFERENCE TEXTBOOKS:
1. Adeoye C.L. (1979) Àsà àti ise Yorùbá Oxford University Press Limited
2. J.A. Atanda (1980) An introduction to Yoruba History Ibadan University Press Limited
3. Adeomola Fasiku (1995) Igbajo and its People Printed by Writers
Press Limited
4. G.O. Olusanya (1983) Studies in Yorùbá History and Culture Ibadan University Press Limited.
5. Rev. Samuel Johnson (1921) The History of the Yorubas A divisional of CSS Limited.