Igbagbo Awon Yoruba

From Wikipedia

ADÉDOYIN, ABASS ADÉGÒKÈ


ÌGBÀGBÓ ÀWON YORÙBÁ

Ìgbàgbó ni ohun tí àwon ènìyàn ìletò kan gbà lati máa se nípa sínsin Olórun tàbí bíbo Òrìsà won lóòrèkóòre. Gbogbo ohun to ba selè nípasè sínsin tabi bíbo Olórun tàbí Òrìsà náà ni àwon ènìyàn náà yóò gbà gégé bi àyànmó won. Irú awon wònyí ni a n pe ni onígbàgbó. Iyen ni pe awon to gba Igbagbo gégé bi ohun kàn-ń-pá. Ki awon Oyinbó to ko esin àtòhúnrìnwá wá sí ilè àwa ènìyàn dúdú (African) ni ìgbàgbó ti wa láàrin awon Babańlá wa. Eleyìí maa n waye nípasè èsìn abòrìsà tí ó wópò ni ilè Áfíríkà. Gégé bí àpere ni ilè Nàìjíríà àwon Olùsin àti Olùbo àwon orìsà ní ìgbàgbó púpò nitori pe nípasè bíbo àwon òrìsà wonyi, òkè ìsòro won máa n di pètélè. Bí o tilè jé pe àwon miran rò pe awon Yorùbá kò mo Olorin nípa àìmo-kan-àimò-kàn won sùgbón bi a ba wo ìse àti àsà àwon Baba-ńlá wa a o mò pé yàtò sí pe wón mò pé Olórun ni oba ti tí ó ga jù, wón tilè gba pe kò si oba míràn léyìn rè ati pe olórun yìí tí won tun mò gégé bí olódùmarè ni Oba tí o ju gbogbo oba lo. Olórun fún rarè túmò sí Olú-orun, eyi ni eni to ni òrun. Bakan náà ni Olodumarè tumò si olódù-omo-àrè tíi se eni ńlá ti ó tobi ti ko si ni àfiwé. Awon Orúko tàbí oríkì miran ti a fun Olórun fi ye wa gbangba pe awon Yorùbá gbà pé Olórun wà. Fùn àpere Olúwa túmò sí ‘Ògá gbogbo wa’ ní itúmò eréfèé. Oríkì isalé yìí ti Yorùbá fun olórun yoo tan ìmólè si ohun ti a n so:-

Adani-waye. Elédàá, Asèdá,

Oba tíi pa Ojó ikú dà

Oba Àjíkí

Olówó-gbogbogbo-tíi-yo-‘mo rè l’ófìn

Òyígíyigì, Ò-pabi-dà, Sobidire

Oba-àìrí, Oba tí kìí sá,

Atérerekáyé

Ògbàgbà-tí-í-gba-ará àdúgbò

A-tóó-gba-ni lójó ibi


Ó dabi pe ìbèrù ti awon Yorùbá ni nínú Olórun yìí ni ó fún won ni ìgbàgbó tí wón ní nínú ikú ati àjínde. Ìbásepò wà láàrin àwon òrìsà tabi Òòsà ilè Yorùbá àti Olódùmarè. Igbagbo awon Yorùbá ni pe àwon Òòsà wònyí jé alágbàwí láarin won àti Olódùmarè. Won sì gbàgbó pe awon Òòsà wònyí ni won lè rán sí Olódùmarè yálà lati toro ohunkohun lówó re tàbí dúpé fún ohun tó se fún won. Èrò yìi han nínú òwe Yorùbá tó so pé “eni mojú owá la ń bè sówá, Olójú owá kan kò sí bí kose ayaba”. Nitori náà Òòsà wà ni ìpò alágbàwí láàrin àwon abòòsà àti Olódúmarè. Bi a ba si gbo ti awon Yorùbá ba so pe ori mi o tàbí Olojo-oni o, Olódúmarè ni won ń pe ni ori, èyí ti o dúró fún eleda ori àti olójo oni, èyí ti o dúró fún eni ti o ni Ojo oni. Awon Yorùbá ní igbagbo to fesèrinlè nipa ìsomolórúko, won gba pe àwon eni wo to ti ku lo tun padà si ayé fun apeere oruko bii ìyabò, Babatúndé, Babajídé, Enílolóbò ati béèbéè lo. Iru àwon orúko wònyí fi yeni pe awon to lo lo tún padà wá. Awon orúko àbíkú bíi Aríorí, Enìgbàkan, Rófìmí ati béè béè lo náà fi igbagbo won hàn, èyí fihàn pe orúko niro omo. Ìgbàgbó àwon Yorùbá nipa àjínde léyìn ikú tún jé ònà miran. Bi a ba ye bi a ti se ń sin òkú ni ilè Yorùbá wò, a o mò pé a gbà pé bí won bá tilè kú won yóò tún jí dìde. Won yóò lo si ilè ibòmíràn lati lo máa se ilé ayé lo ni, ìdí nìyí ti o fi ye pe bi ènìyàn bá kù won a ni ‘ó pa ojú dé tabi ó pa ipò dá’. Nítorí irú ìgbàgbó báyìí ní í máa mú kí a máa sin àwon erú mo òkú awon àgbàlagbà bí oba, Ológun àti bee bee lo láyé àtijó. Irú àwon erú wònyí ni wón gbà pé won yoo máa se ìrànwó fún eni ń lá yìí níbi kibi ti o ba tún jinde sí. Yàtò sí èyí bi òkú òfò ba ku, ti àwon ènìyàn si gba pe ejò lówó nínú, wón lè lo sí orí sàréè rè kí won si pèé ki o si jade lati fi enu ara re so ohun tí o fa sábàbí ikú oró ti o kú náà. Igbagbo pe ajinde wa léyìn iku ni o fa bíbo ti a n bo àwon eni wa ti o ti ku ti a si fi bee so won di Òrìsà àkúnlèbo. Bi a ba ye bíbo egúngún àti gèlèdé ní ilè kétu àti ègbádò wò fínnífínní a o ri pe èyí ń fi ìdí ìgbàgbó àwon baba ńlá wa lórí ikú àti àjíndè múlè ni. Won si gba pe irú awon eni wa bee tí wón jé akínkanjú ti won si ti pèhìndà béè lè jé alárinà láàrin àwa àti Olórun. Yorùbá bo won ni ‘òrò ti akúwárápá bá so ará òrin ló so ó’, kìí se awa Yorùbá nìkan ni a ni irú ìgbàgbó yìí ó dàbí pé gbogbo èsìn ni ó níi Jésù ni àwon onígbàgbó elésin Kírísítì so di alarina láàrin won àti Olórun won léyìn ti ó ti kú tan. Ìdí nìyí ti wón fi maa ń pè é ni Alágbàwí won. Awon elésìn mùsùlùmí gbà pé mòńmódù ni alárinà láàrin won àti Olorun. Awon ti ń sín Búdà gbà pé òun ni alárinà láàrin won àti Edédàá won. Awon Yorùbá máa pa lówe pe ‘ayé lójà òrun nílé’ Ìdí ní pé wón gbà pe bí ènìyàn ba di arúgbó tí o si lo ibi àgbà ń rè yoo lo sí òrun tààrà ni. Sùgbón tí ó bá je òkú òròjú ni yoo bo agò ti àkókó sílè, yoo si tun máa lo gbé ibòmíràn títí ojó tí ó dá yo fi pé. Àkúdàáyà tàbí akuhan ni awon Yorùbá maa n pe iru eni béè. Nítori náà bí a ba wo ìgbàgbó àwon Yorùbá ni àwòfín, a o rí pe wón gbà pé ojókan ń bò ti a ó pàdé lálákeji ati pe ibe ni ilé tí a o fàbò sí. Èyí ni pe bi o ti wù kí a pe láyé tó a o pe lórun jù béè lo. Won ní, ma fòrun yòmí gbogbo wa là ń lo. Bákan naa ni Yorùbá tun gba pe ìdájó ń be àti pe ìdènà orun ni Olúkúlùkù yoo ti jábò isé owó rè láyé. Idi niyi ti won fi maa n wi pe ‘ejó ń be l’órun à-wí-fowóbojú’. Gbogbo èyí ní ó tun fi ese ìgbàgbó àwon Baba nla wa nínú iku ati àjínde hàn. Bi a ba wo ìgbàgbó nipa èsìn ìbílè a o ri pe àwon Yorùbá kò kèrè rárá. Àwon Yorùbá ni ìgbàgbó sí àwon Òrìsà won láti ìbèrè pèpè kí àwon elésìn mùsùlùmí àti elésin kírísítì to dé sí ilè ènìyàn dúdú. Nípa ìgbàgbó won, Ohunkohun ti won ba si toro lówó òrìsà won ti won máa n bo lóòrè kóòrè ni wón máa ń rí gbà lowo òrìsà won. Irú awon òrìsà wònyí ni Obàtálá, òrúnmìlà, Èsù, Ògún, Sàngó, òrisà oko, Oya, Egúngún, Osun òrìsà ìbejì àti béè béè lo. Bí ó tilè jé pé òpò àwon òrìsà wònyí ni wón jé ènìyàn télè kí won tó di òrìsà àkúnlèbo bóyá nípase akíkanjú won tàbí ohun ti won ti gbé se lókè erùpè. Bíbo àti sínsìn àwon òrìsà wònyí máa ń jé mímó lópò ìgbà. Ìgbágbó awon Yorùbá sí awon òrìsà wònyí ni o fà á ti won fi ni òwò àti ìmótótó sí won. Won kìí rú òfin òrìsà béè ni won kìí hùwà àìto sí won. Bákan náà ni won kìí búra eke àti pé iró pípa kìí wáyé pelu ilè dídà. Wón gbà pé òrìsà kìí fi òrò se ègbé, bi òrò bá ti ri ni i so, fún àpeere ojú esè ni sàngó máa n dájó fun eni to ba búra eke. Òrun sì lèrò eni to ba dalè òrìsà tó sì búra èké. Ìmúra àti ètò awon elésì ìbílè ní ojúbo ń fi ìwà mímó tí ó pò hàn, fun apere aso funfun tí kò ní àbàwón ni a máa ń rí lára OlÓbàtálá, aso osùn tó mó ni ti elégùn Sàngó. Bakan náà ni gbogbo ohun jije won náà máa n jé mímó pèlú. Bi a ba wa fi awon nnkan wònyí we àwon èsìn kírísítì àti èsìn mùsùlùmí ti wón gba òde lásìkò yìí, a o ri pe won férè bára mu, ìyàtò tí ó wà níbè ni pé awon elésìn àjèjì ń pe awon nnkan òkè yìí ni òfin nígbà tí ti ìbílè ń pe tiwon ní èèwò. ‘Bòwò fún Baba àti ìyá re ti kirisiti naa ni Omo awo kò gbódò hùwà Òyájú tàbí àrífin sí ògá nibi èsìn ìbílè.

ÌWÉ ÌTÓKASÍ

Sùpò ìbíkúnlé (1970):- Ìwé ìjìnlè Yorùbá Apákejì, Ìbàdàn OUP.

Dáramólá ati Jéjé (1970) Awon Àsà àti Òrìsà ilè Yorùbá bá, Ibadan O U P.

Omosade J.A. (1996) Yorùbá Beliefs and Sacrificial Rites, USA Longman.

Owólabí, Olúnládé, Olábíntán ati Adérántí (1986) Ìjìnlè Èdè ati lítírésò Yorùbá. Iwe kejì. Ìbàdàn, Evans brothers.