Isele Kayeefi

From Wikipedia

Isele Kayeefi

C.O. Elegbeleye

C.O. Elégbéléye, (2005), “Àgbéyèwò ìtàn Ìsèlè Kàyééfì lórí Rédíò’, Àpilèko fún Oyè Eémeè, DALL, OAU, Ifè, Nigeria.


[edit] ÀSAMÒ

Nínú isé yìí, a gbìyànjú àti se àgbéyèwò ewà, ìhun àti èdè nínú ìtàn ìsèlè kàyéèfì Yorùbá lórí rédíò. A sapá láti wo àwon ìtàn ìsèlè kàyéèfi tí wón ń so nínú àwon ètò bí i “Gba-n-kogbì”, ‘Ó-séléńké-jò” “Òwúyé” àti “Tatíwere”. A sì tiraka láti wo àwon ìsèlè ìyànu tí ó súyo nínú àwon ìtàn yìí lórí rédíò.

Onà pàtàkì tí a gbà se ìwádìí ni síse àbèwò sí ilé-isé méérèrìn tí a yàn láàyò fún isé yìí, pèlú èròngbà láti gba àwon èròjà tí a nílò. A gba ìtàn ìsèlè kàyéèfì méjìléláàdóta sílè. Díè lára ìtàn yìí la gbà sílè pèlú téèpù nígbà tí a sì gba àwon mìíràn láti òdò àwon olóòtú ètò náà. Àwon ilé-isé rédíò ti a lo Ilé-isé Rédíò ti Ìpínlè Òsun, lókè Baálè ní Òsogbo, ilé-isé Rédíò Ìpínlè Ondo àkókó lóríta Òbèlé ní Àkúré, Ilé isé Rédíò lóríta Basòrun, Ìbàdàn àti Rédíò amìjìnjìn lókè Màpó, Ìbàdàn. A tún se ìfòrò-wáni-lénu-wò pèlú àwon Gííwá Ilé isé Rédíò wònyìí ní òkòòkan àti àwon olóòtú ètò ilé isé mérin òkè yìí lórí irúfé èdá ìtàn, orú ìtàn tó jé, ètò àgbékalè ìtàn láti mò bóyá ìtàn ìsèlè-ojú ayé ni. A tún sé ìwádìí lórí ipa àwon onígbòwò ètò wònyìí àti èrè won lórí ètò yìí. A se àbèwò sí ilé-ìkàwé fún ìwádìí lórí àwon ohun tí ó je mó àkosílè lórí isé yìí. A se àdàko àbò oko ìwádìí. A sì fi tíórì ìlànà ìmútànso se gbogbo àtúpalè tí a gbà sílè.

Ìsé ìwádìí yìí se àseyorí nípa síse àfikún ìmò lórí ètò ìtàn ìsèlè kàyéèfì Yorùbá lórí radio. A rí pé ó jé ètò tó gbájú gbajà, tó sì se àkópò ìmò àwon ènìyàn nípa ohun tó ń selè tó je mó àsà àti ìse wa. Won ń gbé ètò náà kalè nípa síse àmúlò onà èdè bíi ìpanilérìn-ín àti orísìírísìí ìyapa. Asì rí pé ìkóniláyàsókè jé ogbón ìsòtàn pàtàkì. Ìtàn wònyìí kojá òye èdá lórí ìsèlè ojoojúmó, ó jo ni lójú púpò gidigidi, àwon ìtàn wònyìí kún fún ìsèlè ìyànu, tó mèrù bani, àwon ìsèlè tí a lérò pé kò lè selè ní àwùjo tó wá ń selè tó kóni láyà je, tó sì yàtò sí ìwà omolúwàbí. Àwon ìwà bíi ká fi ènìyàn se òògùn owó, lílo agbára òkùnkùn tó le. Ìlò èdè àwon olóòtú, ètò ìtàn ìsèlè kàyéèfì jé èyí ló lówúra, tó kún fún àkànlò èdè, èdà òrò, àti àmúlò òwe tó bójú mu. Àwon se àmúlò àwítúnwí, àpèjúwe, àfiwé, orin kò gbéyìn rárá. Pàtàkì èyí ni láti fi ewà ètò náà hàn. Nígbà mìíràn, asòtàn lè pín odidi ìtàn ìsèlè kàyéèfì kan sí ònà méta tàbí mérin ìdí èyí ni láti fi ààyè gba ìpolówó-ojà àti láti jé kí àwon àwon olùgbó ètò kó ipa pàtàkì nípa síso èrò okàn won. Asòtàn á wá so ìtàn náà ní sísé-n-tèlé fún òsè méta tàbí mérin ní ìbámu pèlú bí àsòtàn se pín-in.

Ní ìparí, a fi ìdí rè múlè pé ìtàn ìsèlè kàyéèfì ara lítírésò alohùn Yorúbá ni. Ní pàtàkì òpò àbùdá tó je mó èyà lítírésò alohùn bí i òwe, ìfòròdárà, àwàdà, àsorégèé ló wópò nínú ìtàn wònyí. Ìrètí wa ni pé isé ìwádìí yìí yóò jé àtègùn tí àwon isé mìíràn lórí rédíò yóò máa gùn lé lójó iwáju.



Alábòójútó: Prof. Bádé Àjùwòn

Ojú-Ìw é: 186


C.O. Elégbéléye, (2005), “Àgbéyèwò ìtàn Ìsèlè Kàyééfì lórí Rédíò’, Àpilèko fún Oyè Eémeè, DALL, OAU, Ifè, Nigeria.


ÀSAMÒ

Nínú isé yìí, a gbìyànjú àti se àgbéyèwò ewà, ìhun àti èdè nínú ìtàn ìsèlè kàyéèfì Yorùbá lórí rédíò. A sapá láti wo àwon ìtàn ìsèlè kàyéèfi tí wón ń so nínú àwon ètò bí i “Gba-n-kogbì”, ‘Ó-séléńké-jò” “Òwúyé” àti “Tatíwere”. A sì tiraka láti wo àwon ìsèlè ìyànu tí ó súyo nínú àwon ìtàn yìí lórí rédíò.

Onà pàtàkì tí a gbà se ìwádìí ni síse àbèwò sí ilé-isé méérèrìn tí a yàn láàyò fún isé yìí, pèlú èròngbà láti gba àwon èròjà tí a nílò. A gba ìtàn ìsèlè kàyéèfì méjìléláàdóta sílè. Díè lára ìtàn yìí la gbà sílè pèlú téèpù nígbà tí a sì gba àwon mìíràn láti òdò àwon olóòtú ètò náà. Àwon ilé-isé rédíò ti a lo Ilé-isé Rédíò ti Ìpínlè Òsun, lókè Baálè ní Òsogbo, ilé-isé Rédíò Ìpínlè Ondo àkókó lóríta Òbèlé ní Àkúré, Ilé isé Rédíò lóríta Basòrun, Ìbàdàn àti Rédíò amìjìnjìn lókè Màpó, Ìbàdàn. A tún se ìfòrò-wáni-lénu-wò pèlú àwon Gííwá Ilé isé Rédíò wònyìí ní òkòòkan àti àwon olóòtú ètò ilé isé mérin òkè yìí lórí irúfé èdá ìtàn, orú ìtàn tó jé, ètò àgbékalè ìtàn láti mò bóyá ìtàn ìsèlè-ojú ayé ni. A tún sé ìwádìí lórí ipa àwon onígbòwò ètò wònyìí àti èrè won lórí ètò yìí. A se àbèwò sí ilé-ìkàwé fún ìwádìí lórí àwon ohun tí ó je mó àkosílè lórí isé yìí. A se àdàko àbò oko ìwádìí. A sì fi tíórì ìlànà ìmútànso se gbogbo àtúpalè tí a gbà sílè.

Ìsé ìwádìí yìí se àseyorí nípa síse àfikún ìmò lórí ètò ìtàn ìsèlè kàyéèfì Yorùbá lórí radio. A rí pé ó jé ètò tó gbájú gbajà, tó sì se àkópò ìmò àwon ènìyàn nípa ohun tó ń selè tó je mó àsà àti ìse wa. Won ń gbé ètò náà kalè nípa síse àmúlò onà èdè bíi ìpanilérìn-ín àti orísìírísìí ìyapa. Asì rí pé ìkóniláyàsókè jé ogbón ìsòtàn pàtàkì. Ìtàn wònyìí kojá òye èdá lórí ìsèlè ojoojúmó, ó jo ni lójú púpò gidigidi, àwon ìtàn wònyìí kún fún ìsèlè ìyànu, tó mèrù bani, àwon ìsèlè tí a lérò pé kò lè selè ní àwùjo tó wá ń selè tó kóni láyà je, tó sì yàtò sí ìwà omolúwàbí. Àwon ìwà bíi ká fi ènìyàn se òògùn owó, lílo agbára òkùnkùn tó le. Ìlò èdè àwon olóòtú, ètò ìtàn ìsèlè kàyéèfì jé èyí ló lówúra, tó kún fún àkànlò èdè, èdà òrò, àti àmúlò òwe tó bójú mu. Àwon se àmúlò àwítúnwí, àpèjúwe, àfiwé, orin kò gbéyìn rárá. Pàtàkì èyí ni láti fi ewà ètò náà hàn. Nígbà mìíràn, asòtàn lè pín odidi ìtàn ìsèlè kàyéèfì kan sí ònà méta tàbí mérin ìdí èyí ni láti fi ààyè gba ìpolówó-ojà àti láti jé kí àwon àwon olùgbó ètò kó ipa pàtàkì nípa síso èrò okàn won. Asòtàn á wá so ìtàn náà ní sísé-n-tèlé fún òsè méta tàbí mérin ní ìbámu pèlú bí àsòtàn se pín-in.

Ní ìparí, a fi ìdí rè múlè pé ìtàn ìsèlè kàyéèfì ara lítírésò alohùn Yorúbá ni. Ní pàtàkì òpò àbùdá tó je mó èyà lítírésò alohùn bí i òwe, ìfòròdárà, àwàdà, àsorégèé ló wópò nínú ìtàn wònyí. Ìrètí wa ni pé isé ìwádìí yìí yóò jé àtègùn tí àwon isé mìíràn lórí rédíò yóò máa gùn lé lójó iwáju.



Alábòójútó: Prof. Bádé Àjùwòn

Ojú-Ìw é: 186