Ise Ona Ara Opon Ifa

From Wikipedia

Ise Ona Ara Opon Ifa

OHUN TÍ ISÉ ONÀ ARA OPÓN IFÁ Ń SO1

Contents

[edit] ÌFÁÁRÀ

Yorùbá bò, wón ní a-sáré-inú-èkan kà sá lásán, bí kò lé nnkan, nnkan ni ó ń lé e. Ó férè má sí opón Ifá kan tí kò ní isé onà lára. Isé onà kòòkan sì ni ó ní isé pàtàkì kan tí ń jé fún aráyé, pàápàá oníbèéèrè àti Babaláwo, bí ó tilè jé pé kò lè ya enu sòrò gégé bí ènìyàn. Isé tí ó sì ń jé yìí kò sàìyé àwon tí ń jé irú rè fún,. gégé bí Oyin Ògúnbà (1978:23) ti sàlàyé nígbà kan rí. Sùgbón òrò wo ni isé onà kòòkan ń so? Isé wo ni ó ń jé? N óò fi èyí bàn nínú àlàyè tí n óò se báyìí.

[edit] ÌRÍSÍ OPÓN IFÁ

Lápapò, Opón Ifá lè rí kìrìbìtì, kí ó yípo, tàbí kí ó ní igun mérin2 (Abímbólá, W; 1977:9). Bí ó bá se kìrìbìtì, ohun tí ń fi hàn nip é òkìrìbìtí ni gbogbo ayé; se ni ayé yípo. Bí ó bá sì ní igun mérin, ó tún ń fi “orígun mérèèrin ayé” hàn bákan náà ni, gégé bí Wándé Abímbólá (1975:19) ti so. Ohun tí ìrísí kìíní-kejì yìí ń so ni pé àsírí gbogbo ayé pátá porongodo ń be lówó Ifá; gbogbo àbáyé ni òún rí; kedere sì ni ó ń wo gbogbo ohun ìkòkò tí ó sá pa mó fún èdá ní abé òrun. Òun ni “Elérìí ìpín, Òpìtàn…Ifè” (Abímbólá, W; 1976: 4; 10, 115).


Léhìn náà wàyí, gbogbo ara opón Ifá ni ó gún; gbágungbàgun kankan kò sí níbè rárá. Isé tí èyí ń jé nip é Ifá nìkan, tí òrò òun fúnra rè gún gégé, ni ó lè tó òrò elòmìí ti ó wó gún bí onítòhún bá sá tò ó. Ifá sáà ni “Òkítíbìrí a-pa-ojó-ikú-dà” (Lucas, O; 1948:75).

Perese tí inú opón Ifá téjú pàápàá kò sàìní isé tí ń jé. Ó ń fi hàn pé Ifá a máa fi inú han oníbèéèrè. Kò ní kòlòkóló kankan nínú rárá. Béè sì ni kì í sé òrò kù bí yóò bá dá enikéni ní ìmòràn. Ìdí ni èyí tí a fi lè fi okàn tán an, tí a si i lè fi òrò tí ń dunni lo ó fún ìmòràn. Sé kò kúkú ni í tanni jé nítorí pé òun ni “A-kóni-lóràn-bí-ìyeka-eni” (Abímólá, W; 1969:16).

Opón Ifá kojú sóke ni; kì í dojú délè. Ó fi hàn pé gbogbo ìgbà ni ó wa lójúfò. Ifá kì í sùn rárá. Tojú-tìyé ni òun fi ń reran gégé bí àparò. Lójúlójú sì ní í wo eni tí bá ń sòrò fun. Sé òpùró ní í dojú bolè; pòn-ún sì là á sòrò, mo-ni-mo-ní là á seke; sàn-án là á rìn, ajé ní í múni pekoro. Èyí nìkan sì kó. Ifá tún ń so pé òun ń gbé ilé ayé mo ohun tí ń lo lórun sé. Bí okùn ile ayé bá fé já,. òun ní í tún un so. Ti òrun pàápáà, bí ó bá wà ní sepé, Olódùmarè kò sàìmò pé ìrànlówó tí òun se tí ó fir í béè kì í se kèréémí. Òun Ifá ni “Gbáyégbórun”. (Abímbólá, W; 1969:9).

Àwòrán onírúurú èdá ni ó tò geerègè yí opón Ifá ká. Èyí ń fi hàn pe iloé ayé kún fún orísìrísi èdá. Bí ènìyàn ti wà ni erano wà. Bí ati rí èdá tí ń gbé inú omi gégé bí eja ni a rí èyí tí ń gbé orí ilè gégé bí ewúré, tí a sì rí èyí tí ń fò kiri ní ojú òruin gégé bí eye. Bí a sì ti rí èdá rere ni a tún ti rí èdá búburú. Kódà, bí a bá rí orísI èdá kan, gégé bí eja, ní apá òtún opón b;í a bá rí orísi èdá kan, gégé bí eja, ní apá òtún opón Ifá, a óò tún rí orísi kan, náà ní apá òsì rè. Ohun tí èyí ń so sì ni pé méjì-méjì ni Olódùmarè dá nnkan ní ilé ayé. Ó dá won ní ìjora, gégé bí ó ti rí nínú èyà ara tí etí òtún jo ti òsì, tí ìyé eyelé òtún jo ti òsì, tí àgbébò fi gbogbo ara jo àparò, tàbí ní ìtakora gégé bí òsán ti yàtò sí òru, tí ìtumò tí eja ní sì yàtò sí ti akàn nínú ìgbàgbó àwon Yorùbá. Ní sókí, tibi-tire ni ilé ayé; eye kì í sì í fi apá kan fò. Ohun tí ó fà á níyí tí ó fi jé pé abala méjì ni Odù kòòkan, títí kan àmúlù Odù pàápàá, ní nínú Ese Ifá. Bí a sáà ti ń rí Èjì Ogbè àti Òbarà Méjì náà ni à ń rí Ogbèyèkú àti Ogbèbàrà. Eyelé so nínú Èjì Ogbè (Abímbólá, W; 1976: 206-207) pé: …

Èjèèjì ni mo gbè,

N ò gbenì kan soso mó

… Èjèèjì ni mo gbè …

Síbè bí ó ti wù kí gbogbo èdá tí ń be ní àgbáyé pè tó, ti pé wón pagbo rìbìtì yí Ifá ká, tí Òrúnmìlà wá wà ní àárín, fi hàn pé ipò pàtàkì tí ó ye “Obàrìsà”(Abímbólá, W; 1977:xi-xii) tí òun jé ni wón fi í sí. Enì kan kò sì bá a dù ú. A kì í bá yímíyímí du imí. Kàkà béè, se ni gbogbo won gbárùkù tì í gégé bí alákòóso won pàtàkì. Kódà, gbogbo èdá yòókù ní í wò ó fún ìrànlówó àti ààbò. Ògúndá Méjì (Abímbóla, W; 1968:102-103) ni akápò Ifá ti so pé: … Ifá, ràtà bò mí,

Ibí pò lóde … Nítorí náà àti eégún, àti Òòsà, àti ènìyàn, àti eranko – gbogbo won ni wón ní í se pèlú Ifá. Bí a bá sì rí àwòrán èyíkéyìí nínú won létí opón Ifá, kí á mò pé isé tí Ifá ń rán an ní í jé níbè. Sùgbón kí ni isé tí òkòòkan àwon èdá tí a yá ere won sí etí opón Ifá ń jé? Kí ni ohun tí ń so? N óò sàlàyé òkòòkan báyìí.

Èsù Àárín gbùngbùn tí yóò ti lè máa wo Babaláwo lójú kòrókòró báyìí ni àwòrán Èsù wà lára àwon àwòrán yòókù létí opón Ifá. Ipò tí ó ga jù lo ni èyí. Ó sì níbá tí ó fi rí béè. “Èsù ni aláse fún gbogbo àwon òrìsà…omo òdò Èsù ni gbogbo àwon ajogun” (Abímbólá, W; 1977:xxiii). Òun ló ń ti ènìyàn tí ó fi ń se àwon èdá wònyí (Bólájí Ìdòwú, 1962: 83) tí ìdààmú fi ń dé bá a tó béè tí yóò tún fi fúnra rè fa olùpónjú náà to Babaláwo lo láti wádìí ohun tí ń da òun láàmú (Awólàlú, J.O; 1979: 29). Òun kan náà sì ni ó wá jérìí sí ohun tí Babaláwo ń se báyìí. Njé Babaláwo yóò “se é bí wón ti ń se é kí ó lè bàa rí bí ti í rí”? Èsù fé mo àmòdájú èyí.


Fún gbogbo ìsapá rè, Èsù wà níbè láti gba “aárùún tirè…(nínú)… gbogbo ebo tí a bá rú” nítorí pé:

Èsù ní í gba ebo

Béè ni kò mo Ifá á dá

(Abímbóla, W; 1977:xxiii).

Bí ó bá sì ti mú tirè, òun kan náà ni yóò gbé ìyókù dé ibùdà.

Kí á sáà ti so pé bí kò sí ti Èsù, Ifá kì bá tí rí eni wá sebo. Bí kò sí sí ebo, gbogbo ìbo ni ebi ì bá máa pa ní àpaàsíwó. Nítorí náà, àjospò tí ń be láàárín Ifá àti Èsù ga ju kí á wá Èsù kù ní ibi tí Ifá bá wà. Bí ìgbín fà, ìkarawun ń tè lé e ni. Òrò ebo rírú kì í sáà ń se kèréémí nínú Ifá. Ení rúbo lÈsù ń gbè (Abímbólá W; 1977: xix). Eni tí ó sì “dá wòn-ín” (Yémitàn, O. & Ògúndélé, O. 1970:4) Ifá ní í ko àgbákò Láàlú. Kálukú a ní:


Èsù mó se mí,

Omo elòmíìn ni o se.

(Àjùwòn, Bádé, 1972:5).

[edit] EYINDÌE

Èyí ń fi hàn pé elegé gbáà ni Ifá dídá; kí àti Oníbèérèré àti Babaláwo sóra se. Eni òrò bá ti owó rè bó rélè nínú won ru igi oyin; àtapa sì ni!

Ó tún ń fi han oníbèéèrè bákan náà pé òrò tí ó mú wá kò sòro ó yanjú rárá, gégé bí eyindìe kò ti sòro ó fó; kìkì bí ó bá ti lè tè lé ìmòràn Ifá ni sá o! Kò mú towó rè wá kò lè gba towó eni.

[edit] EYELÉ

Eyelé ń so fún oníbèéèrè pé ire ń be lótùn-ún lósì fún oníbèéèrè láti kó lo ní òdò Babaláwo bí ó bá ti se ohun tí Ifá wí. Tòtún-tòsì kúkú ni eyelè fi í kó ire wálé.

Eyelé ń rán Babaláwo létí pé kí ó má se da Ifá gégé bí òun àti Èjì Ogbè ti mulè tí won kì í sì í da ara won. Nítorí náà, kí Babaláwo se ètó.


Eyelé ń se ojú fún àwon eye yòókù. Eye, pàápàá èhurù sì ni àmì àwon Eleye. Nítorí náà, Babaláwo níláti rántí àwon Eleye kí ó sì tù wón lójú. Bí béè kó, won yóò ti esè òsì bo ohun tí ń se.

[edit] EJA ÀTI EWÚRÉ

Ara oúnje Ifá ni eja àti ewúré í se. Ifá a máa gba:


Eku méjì olùwéré,

Eja méjì abìwègbàdà;

Ewúré méjì abàmúrederede;

Einlá méjì tó fìwo sòsùká;

Eye méjì abìfò ga-n-ga.

Ata tí ò síjú,

Obì tí ò làdò,

Otí abóda

(Abímbólá, W; 1977: xxiii)


lówó oníbèéèrè gégé bí èrù. Nítorí náà, eja àti ewúré ń sojú fún àwon yòókù ni. Wón sì ń so fún oníbèéèrè pé kí ó má fi ebo saló. Dípò béè kí ó wá oúnje sí enu ìbo. “Olúbòbòtiribò (ni) baba ebo” (Abímólá, W; 1976: 38-39). Bí enú bá je, ojú a tì. Ebo kéékèèké sí ní í gba aláìkú là.

Lónà kan, ejá dúró fún èrò pèsè nítorí pé ilé eja kì í gbóná, tútù là á bá ilé eja. Àmì ire jèbútú omo sì ni ó jé. Sùgbón lóna mìíràn, ó dúró fún “béè-kó”. Bí wón bá ní “eja ni”, ó túmò sí pé nnkan náà kò senuure nìyen. Ohun tí èyí wá ń fi hàn nip é eja ni òrò oníbèéèrè yóò jé bí ó bá


…pawo lékéé,

Ó pÈsu lólè,

Ó wòrun yàn-yàn-àn-yàn

Bi eni tí ò ní i kú mó dáyé,

Ó wá á kotí ògboin sebo…

(Abímólá; W; 1969 : 43)

Yàtò sí pé àwon Eleye ń lo ààyè ewúré fún isé ibi won, àwon Babaláwo a máa fi ìfun rè pèèsè fún àwon Eleye (Abímólá, W; 1969:86). Nítorí náà, ó wà ní etí opón Ifá gégé bí ohun ti Babaláwo fi ń tu àwon Eleye lójú kí ó bàa lè rí ojú rere won.

[edit] ÒPÈLÈ

Òpèlè ni ohun àsárémú tí Babaláwo fi ń dá Ifá dípo Ikin. Nítorí náà, a lè so pé òun ni ó ń rán Babaláwo létí pé Ifá ń wo ohun tí ń se kòrókòró; isé tí Ifá rán an sì ni kí ó jé láiku eyo kan.

Sùgbón bí a bá rántí pé ìgbàkígbà tí Babaláwo bá ti ń lo opón Ifá, kò lè se kí ó má lo ikin, a lè béèrè pé kí tún ni ìwúlo òpèlè nígbà tí ikin tí Òrúnmìlà fi dípò ara rè níjó kìíní ti wà? Ìdáhùn fún èyí kò lo dan-in. Bí gbogbo ohun tí ń sojú fún Ifá bá wà ní àrówótó Babaláwo báyìí, yóò jé ki òun pàápàá mò pé kò sí ibì kan tí ó pamó kúrò lójú Ifá nínú gbogbo ohun tí òun ń se. Àní ojú tí ó ń wo òun léèkan soso ju igba lo. Kí òun sóra se ni ó tó, tí ó tún ye.

[edit] OWÓ EYO

Ara ìbò tí Babaláwo ń lo ni owó eyo í se. Ó dúró fún “béè-ni”. Àwòrán rè ń fi han oníbèéèrè pé kò sí ohun tí yóò sòro ó tú fún Ifá nínú ìbéèrè rè. Ó nílátí fi okàn balè. Ifá yóò yanjú gbogbo ìsòro tí ń dà á láàmú. Bákan náà sì ni ó ń ki Babaláwo láyà pé kí ó má mikàn, Ifá yóò kó o ní èsì tí yóò fún oníbèéèrè.

Owó eyo dúró fún ohun tí à ń ná. Ó sì ń so fún oníbèérè pé kí ó má sahun rárá; níná ni kí ó ná owó rè: kí ó mééta ìténí, kí ó fi kééjì adìbò, kí ó má sì pábo rú. Arojú-owó kì í sòsó. Bí kò bá ti háwó, ire tójú owó ń rí náà ni tirè yóò rí.

[edit] AKÀN

Èyí ń fi han oníbèéèrè pé ire ni òrò tí ó bá wá yóò já sí kéhìn; tutu bá gbèdègbede tí à ń bó ilé alákàn ni ara yóò tù ú dandan. Àmó yóò kókó jé béè-ni sí ìmòràn Ifá, kí ó mú un sà lóògùn ná. Èhìn náà ni Ifá yóò so òrò rè di akàn, láìse eja.

[edit] ÌKADÌÍ

Kókó pàtàkì kan ni gbogbo àlàyé àtèhìnwá yìí kàn mo okàn eni. Òun ni pé èmí òkòòkan nínú àwon èdá tí àwòrán won hàn ketekete létí opón Ifá ni ó péjú pésè sí ibi tí Babaláwo ti ń dífá. Èyí fún Babaláwo ní ìgboyà pé gbogbo èdá ni ó wà léhìn òun nínú isé tí òun ń jé. Isé náà ì báà dára, ì báà sì burú, dandan ni kí òun jé e. Bí òun bá sì wá sèrú wàyí o, gbogbo àwon èdá wònyí ni yóò dá sèríà tí ó dógbin fún òun. Nípa béè, ètó ni ó tó kí òun se nítorí “igba ojú”tí ń wo òun.


Bákan náà ni wón tún ń mú okàn oníbèéèrè balè pé Babaláwo kò jé tan òun je nítorí àwon elérìí púpò tí wón jo ń wò wón. Béè si ni òrò tí òun bá wá kò lè pa gbogbo èdá wònyí lódà dépò tí òun kò fin í í rí ìdí rè. Àgbà méta kì í pe èkùlù tì. Léhìn náà èwè, oníbèéèrè yóò tún rí èdò fi lé orí òrònro bí ó bá rú ebo tí Ifá kà fún un. Yóò ti mò pé núsojú Òòsà, Eleye, Èèyàn àti eranko ni òun mú àse Ifá se. Ebo òun kò sì ní í sàìdà dandan níwòn bí


“Eégun Ayé

Èsìbá òrun

Irúnmalè Ojùkòtún

Igbamalè Ojùkòsì


(Fábùnmi, M.A; 1972: 3)

ti lówó sí i. Okàn rè a si bàlè gégé bi ti tòlótòló.


Sùgbón gbogbo èdè tí àwon àwòrán wònyí ti ń pé yìí, láìfohùn ni wón ń se é. Kò ye kí ó yà wá lénu nítorí pé:


Òwe ni Ifà ń pa

Òmòràn ní í mò;

Bí a bá wí pé “mò!”

Òmòràn a mò;

Nígbà tí a kò bá mò,

A ní kò se.

(Lucas, J.O. 1948:79).

[edit] ÀKÍYÈSÍ

1. Òmòwé Bádé Àjùwòn ni wón gún mi ní késé nínú kíláàsì YOR 617 láti se isé yìí. Mo sì se é tán, mo ná án hàn wón-òn-òn, wón tún nà mí lógo enu. Àmó Òmòwé Akínwùmí Ìsòlá gbà mí ní ìmòràn pé ó ye kí n wádìí nípa ojú tí àwon Babaláwo fi ń wo ohun tí isé òhún dá lé. Kò sáà ye kí n fá orí léhìn olórí.

Ni mo bá sá to Awo Babalolá Fátóògùn lo ní 17/5/84 (ní yàrá won, AFS Rm 206). Awó kó, Awó rò; ilè sì kún. Sùgbón mo sàkíyèsí pé àlàyé tí wón se lórí òkòòkan nínú àwon àwòrán (isé onà) etí Opón Ifá kò sé, béè ni kò ya ohun tí à ń lo ohun òhún fún. Gégé bí àpeere, Awó ní:


Eku, eja ni Òrúnmìlà fi ń sètùtù fún

Ikú àìlóríta

Ikú júujùu bí ikú emèrè

Ifá gbeku gbeja

Kó o fi sèròrí akápò

… Lójú tèmi, níwòn bí irú àlàyé báyìí kò ti bá

[edit] ÌTUMÒ

tí isé náà dá lé mu, kò ní í túmò sí pé mo ko okà Awo kéré ni n kò fi ìjiròrò tí a jo se kú isé yìí. Béè kó rárá; àgbedò! Kàdà béè, ìtumò tí ó je èmi lógún sùgbón tí àwon kò kó lé okàn ní tiwon ni ó pàdí títa irú àtapínsè béè. Àrùn tí ó se obo kò se igún; orí igún pá, ìdí òbó pá. Ìtumò tí àwon bá se ni mo gbàgbó pé ó ye kí n fi wéra pèlú èyí tí èmí se. Sùgbón nígbà tí won kò se béè yìí ńkó?

Àbá tí n óò wá dá ni pé enikéni ni ó lè pe Babaláwo yòówù kí ó rí tè lórí ìtumò tí mo se yìí. Bí ìmò titun kan bá sì fara hàn nínú irú ìfikùnlukùn béè, mo se tán àtigbó o. Kódà, bèlèjé ni mo té etí mi méjèèjì, sílè; àgbóyé sì ni isé tí n óò fi wón se. Síbè náà, àdáàdátán ni opé mi lódò Awo Fátóògùn. A óò máa rí baba bá o!.

2. Alàgbà Rowland Abíódún ni wón kó só nínú kíláàsì YOR 617 (4/4/84, AFS Rm 204) pé a rí Opón Ifá mìíràn tí ìrísí rè dà bí ìgbà tí a bá la Opón Ifá tí ó se kìrìbìtì sí méjí ogboogba. Mo gbó o lénu won, ó sì ń se mí ní hààhin. Ni mo bá fi í tó Awo Fátóògùn létí (ní 17/5/84) tí wón sì so pé onítòhún to súnà. Orísi Opón Ifá yìí ni Awó pè ní Onípìn-ín-jésù (oní-ìpín-ojó-osù). Síbè náà, ohun tí Opón Ifá onípìn-ín-jósù yìí ń se kò fi béè yàtò sí ti àwon méjì yòókù. Òun ni pé láti apá kan òkun títí fi dé ìlàjì òsà, gbogbo ohun tí ń selè kò sèhìn Ifá; ojú rè tó won pátá porongodo.

OLANIPEKUN OLURANKINSE.

[edit] ÀWON ÌWÉ TÍ MO YÈ WÒ

1. Abímbólá Wàndé (1968) Ìjìnlè Ohun Enu Ifá, Apá Kìíní. Glasgow: Collins.

2. Abímbólá Wàndé (1969) Ìjìnlè Ohun Enu Ifá, Apá Kejì. Glasgow: Collions.

3. Abímbólá Wàndé (1975) Sixteen Great Poems of Ifá. Zaria: UNESCO.

4. Abímbólá Wàndé (1976 Ifá: An Exposition of Ifá Literary Corpus. Oxford University Press.

5. Abímbólá Wàndé (1977) Àwon Ojú Odù Merèèrìndínlógún. Great Britain: Oxford University Press.

6. Àjùwòn, Bádé, (1972) Àdìtú Ìjìnlè ohùn Enu-Ifá, Apa kíini. Ìbàdàn: Onibon-Ojé Press.

7. Awólàbú, J.O. (1979) Yorùbá Beliefs And Sacrificial Rites. Great Britain: Longman.

8. Fábùnmi, M.A. (1972) Àyájó, Ìjìnlè Ohùn Ifè. Ibadàn: Onibon-Oje Press.


9. Ìdòwú, E.B. (1962) Olódùmarè, God In Yorùbá Belief. Great Britain: Longman Nigeria Limited.


10. Lucas, J.O.. (1948) The Religion of The Yorùbás. Great Britain: C.M.S. Bookshop.


11. Ògúnbà, Oyin (1978) “Traditional African Festival Drama” in (eds.) Ògúnbà, O. and Ìrèlé. A: Theatre In Africa. Ìbàdàn: Ìbádàn University Press.

12. Yémiítàn, O. (1970) Ojú Òsùpá, Apá Kejì. and Ògúndélé, O. Ìbàdàn: Oxford University Press.