Ijinle Ede ati Litireso Yoruba 3
From Wikipedia
Ijinle Ede ati Litireso Yoruba 3
Olu Owolabi
Owolabi
Bayo Adereti
Adereti
Taiwo Olunlade
Olunlade
Afolabi Olabimtan
Olabimtan
Olú Owólabí, Báyò Adérántí, Táíwò Olúnládé àti Afolábí Olábímtán (1986), Ìjìnlè Èdè àti Lítírésò Yorùbá: Ìwé kéta. Ìbàdán, Nigeria. Evans Brothers (Nigeria) Publishers Limited. ISNB: 978-167-519-8. Ojú-ìwé 101.
Èyí ni Èketa nínú òwó ìwé wa tí a dìídì se fún lílò lórí èdè Yorùbá ni ilé-èkó Sékóńdìrì àti ilé-ìwé èkósé àwon olùkóni. Gégé bí a ti se nínú àwon ìwé ìsaájú, a ta ogbón láti mú èkó inú ìwé yìí rorùn fún akékòó láti kó, a sì gbìyànjú láti to àwon èkó inú rè ní ònà tí yóò fi derùn fún àwon olúkó láti kó àwon akékòó. Ìsòrí méta pàtàkì ni a pín èkó nípa Yorùbá sí nínú ìwé yìí, èkó nípa gírámà èdè Yorùbá: èkó nípa àsà Yorùbá, àròko kíko; àti èkó nípa lítírésò Yorùbá. Olóyè Olu Owolabi, olùkó àgbà ní egbado College, Ilaro, ni ó gbájúmó èkó nípa àsà Yorùbá àti àròko kíko, Ògbéni Bayo Aderanti ti Oyo State College of Education, Ilésà ló sisé lórí èkó nípa gírámà èdè Yorùbá, Ojògbón Afolabi Olabimtan ti University of Lagos ni ó sì gbájúmó èkó nípa lítítésò Yorùbá (àtenudénu àti àpilèko) ìsòrí métèèta ni a pèsè èkó tí ó péye fún a sì fi èkó wònyí lú ara won kí ó má baà sú àwon akékòó. A se ètò àmúse-isé akékòó ní ònà tí olùkó yóò fi lè máa ni òye kíkún nipa ìwòn ìmò tí àwon akékòó bá ní nínú èkó ìjókòó kan. Nípa báyìí ìbéèrè lórí èkó kòòkan tún jé ìrànwó fún àkàyé. Dájúdájú, èkó akékòó gbódò tún wà lórì àgbóyé àti àsoyé èdè Yorùbá. Nítorí náà ó tó, ó sì ye kí àwon olùkó mò wí pé ogbón àtinúdá tiwon se pàtàkì púpò fún lílo èkó inú ìwé wònyí láti kó akékòó dé ojú àmì. Orísìírísìí ònà ni wón lè gbà láti se èyí. Díè nínú won ni:
1. Mímú àwon akékòó se ìwádìí nípa ewì àdúgbò tiwon alára, kí wón sì wá jé àbò ní kíláàsì
2. Lílo fíìmù àti fídíò tí ó fi ìgbé ayé àwon Yorùbá hàn;
3. Gbígba ohùn àwon akéwì àtenudénu àti ti apàló-padídùn sí orí èro agbòròso;
4. Kíkó àwon akékòó lo wo ayeye eré tàbí odún ìbílè orísìírísìí;