Ife ninu Eko Islam
From Wikipedia
Ife ninu Eko Islam
Tiamiyu Adamo Gbadebo
TIAMIYU ADAMO GBADEBO
ÌFÉ NÍNÚ ÈKÓ ISLAM
Mo bèrè líruko Olórun, Oba Àjoké ayé Àsàké Òrun. Ifé jé nnkan kan gbòógì tó se pàtàkì nínú ìgbési ayé omo èdá yálà nínú ilé ni, láwùjo ni, láàrin lókláya ni, láàrin òbí sómo tàbó láàrin òré sórèé, ifé je’ nnkan tí á kò le yo owó kinlàńkó rè kúrò láwo. Kódà nínú èsìn, ìfé jé nnkan tí a kò le fowó ró séyìn. Látàrí àwon ìdí tí ó wà lókè yìí àti àwon ìdí mìíràn ni Islam fi kó wa lékòó lópòlopò lórí bí ìfé se le rinlè láwùjo omo ènìyàn. Látàrí kí ìfé ó lè rinlè lárìn àwon ènìyàn, Olórun Oba àlekèdá so báyìí ní Al.Qùráni, Ori kokàndìnláàdóta, ese kesàn-án pé: “Àtipé tí ikò méjì bá ńjà nínú àwon olùgbàgbó òdodo, kí é se àtunse láàrin won….” Olórun Oba Àlekèolá tún so báyìí ní Al-Qùránì orí kokàndínláàdóta pe: “Awon Onígbàgbó òdodo kò je nnkan kan ju omo ìyá lo. Nitorínàà, kí won o màa se àtunse láàrin ara won, kí wóm ó wá bèrù Olórun kí won bà le rí àánú gbà”. Ìyen nipé, àwon tí ńbá se àtunse pèlú ìbèrù Olórun lórilè yóò maa rí àánú Olórun Oba gbà. Látará kí ó má bà sí gbónmísí-oùòto, èyí tí yóò sokùnfà kí ìfé ó joba láàrin àwon omo ènìyàn, Olórun Oba tún mún àwon òrò wònyìi wá ní ese kokànlá àti ese kefà tí mèjìjì wá ní orí-kokàndìláàdóta ÀlQùránì. “Èyin olùgbàgbó òdodo, e má se jé kí apákan nínú yín ó ma fi àwon apákan se yèyé nítorípé ó lè jépé àwon tí wón fi ńse yèyé ló tára ju àwon tí ńfìyàn se yèyé lo. Bákannáà, fí àwon òbìnrin kan má se fi àwon òbinrin kan se yèyé, nítorípé àwon ti wón fi nse yèyé leè dára ju àwon tó ó ńfìyàn se yèyé lo. Kí wón máse máa búrawón tàbí parawon lawon orúko tíwon kò faramó. Búwo lose burú tó kí enìkan ma pe enìkan lórúko burúkú bíi “Ìwo elésè”, tàbi “Ìwo burúkú” léhìn tí enì tí à ńpè báyìí ti gbàgbó. Gbogbo enikénì tí kò bá tuba kúrò nibi irú ìsesi báyìí, dájúdájú, irúfé irúwon gan-an ni alábòsí” Ese kokànlá. Èyin onígbàgbó òdodo, tí pòókì (òpùró tàbí enibi) ken bámú èyíkèjíi ìròyìn wá báyin, e se ìwádìí rè dáadáa, kí e má bà ma kolu, àwon ènìyàn pèlú àimòkan àtipé kí e má bà kábàámò aburú lórí ohun tí e ti se nìgbèyìn” Ese kefà. Olórun Oba ńkìlò wònyìí kí àlàáfìa ba le joba láàrin àwon omo ènìyàn èyí tó jé wípé nígbgbèhìn yóò mu ki ifé ó joba láàrin won. Olórun Oba Àlekèolá tí ó mo omo ènìyàn tí ó sítùn mòwà won mò wípé lára nnkan tí ó le máa pa ifé lára láàrin àwon ènìyàn ni eléyìí mèyà, onílùjílùkí. Ìdí nìyí tí ó fi kìwón nílò ní Àl-Qùránì, orí kokàndíníáàdóta ese ketàlá pé: “Eyin Omonìyàn A dáyinń láti ara ako kan àti abo kan, a sì tún pinyin sí àwon ìlú àti àwon èyà kí e lè badarayin mò lásán ni. dájúdájú, enití ó lápòńlé nínú yin jùlo lódò Olórun ni enití ó páyà Olórun jùlo. Dájúdájú, Olórun Oba ni Onímímòjùlo àti Olùfúniníròò”. Olórun Oba Àlekèolá pàtàkì ìfé debi wípé ó pèé ni àmì rè nínú ese ‘Al-Qùránì tí ó ńbò yìí. “Atipé nínú àwon àmì rè nìyí pé ó dá fún yín àwon alábàgbé (Okotàbí Ìyà) àti inú yín, látàrí kí e le máa gbè níròrùn pèlú won, àtipé ó tún fi ìfé àti ìké sínú okàn yín. Dájídájú nínú eléyìí àwon àmìn e fún àwon tó láròjinlè” Àl-Qùránì , Orí ogbòn, ese kokànlélógún. Tí a bá fojúwo gbogbo ese Àl-Qùránì tí ati ń múwá lóke yìí, a ò sàkíyèsí wípé èsìn Islam ko fi owó jábúté mú òrò ìfé. Kò wá tán sibè o, Ànóbí Mùhámmàd (kikèé àti Olà Olórun máa ba) náà sòrò púpò fún àwon mùsùlùmi lórí ìfé. Lára àwon òrò náà ni Ànóbì Mùhámmàd (kíkèé àti olà Olórun mába) so wipe: “Enìkankan nínú yin kò tíì di onígbà gbó òdodo títí ti yóò fi fé fún omonikejì rè, ohun tí ó fé fún èmi ara rè”. Òrò yìí yóò fi rìnlè lókàn enití ó gbo wipe ó gbódò féràn omonì kéjì rè gégè bii ara rè. Nínú òrò mìrán Ànóbì Muhammad (Kíkèé àti olà Olórun máa ba) so pé: Onígbàgbó òdodo kan sí onígbàgbó òdodo kejì dà gégé bíi odidi ilé kan tí a mo pa tí apá kan nínú rè ńgbé apé kejì nígbòwó. Ànóbì (SAW)(1) wá di owó ree méjejì pò láti fi sàpéjúwe eléyìí. Enití ó bá ńwo odidi ilé lítìtóó yóò ríi wípé apákan. Ńgbé èkejì nígbòwó ni. tí apá kan bú lo sèrì yalulè lára odidi ilé kan, eni náà yóò ri wípé ilé yen kòni dùn-ún wó lójú mó. Ibòmíràn, Ànóbì (SAW) fi onígbàgbó òdodo kaa sí èkèjì we odidi ènìyàn kan èyí tójé wípé tí ibakan bá ńdùn eni náà nínú ara, gbogbo ara náà nì kòní gbádùn. Èyí fi yéni pé ìsesí àwon ènìyàn láwùjo siráwon gbódò jé èyí tàbí òwe “Ohun tóbójú lóbámú” mu, èyí tójé wípé tí kò bási ìfé, eléyìí kò le ri béè. Bákaanáà Anóbì Muhammad (SAW) ńbá àwo Nhùsùlùmí sòrò níbi tóti sopé: “Ìgbàgbó enikankan nínú yín kò le tíi tó títí tí e ò fi nífèé ara yín. Sé kín njúwe ohun tí yóò jé kí e nifèé arayìn fún yín? Àwon sàhábé (Àwon tó bá Ànóbì Muhammad (SAW lògbà) ní béènì.O (SAW) ní e máa fón sálàmà (Gbolohun “Asalam Alaykun lalaramatullah Inlabarakatu”tó túmò sí “Àlááfìà Olóhùn, Ìké Olórun àti Ore Àinípèkun rè kó máa bá ìwo tí mo dójúko yìí. Níbi òrò Ànóbì (SAW) tó wà lókè yìí, a o rimú jáde níbè wípé ìfé jé nnken tótobi púpò nínú àlámòrí èdé tóbéè géé tí Ànobì fi lóyò mó ìgbàgbó Bákannáà, fífón tí Ànóbí ní kí wón máa fón sálámà sí enìkan ńso fún enìyèn wípé láti òdò tòun, àláàfìà iké àti ore àinípèkun ni yóò ma bá àtipe èyíkèyìí aburú kòni ti owo òun losí òdò ènìyàn. Ìròri Àwon sàhábé (Àwon tó bá Ànóbì (SAW lògbà). Nipa Ìfé Àwon sàhábé sàmúlò òrò Olórun Oba Àlèkèolá àti ti Ànóbì rè nípa ifé débi wípé ènìyàn yóò sì máa rò wípé ènìyàn abara lásan kólèè se àwon nnkan tí wón se nípa ifé. Àwon ìgbìyànju tí wón se lórí ìfé lo báyìí. Nígbà Ànóbì (SAW) bati àwon sàbábé (RA) rè bèrè síí fón Islam ní Mecca, àwon lárúbáwá tí wón kìíse Mùsùlùmì nígbànáà bèrè sí ní gbé ogun onírandíran tìwón, ìgbàti ogun yìi le dá àyè kan Olórun Oba Àlekèola pàse fún Ànóbí (SAW) àwi àwon Sàhábé rè wípé kìwón fi Mecca sílè losí Mèdìnà fún ìgbà kan ná tí Olórun yóò fi fiwón jerí àwon kèfèri Mecca. Ànóbì Olorun (SAW) àti àwon Sàhábé rè sebéè lótìtóó láìsèsè máa se ìbéèrè ìdí tí Oló Oba Olá Rè gà)fi páwón láse kí wón se béè. Nígbàti wón dé Màdínà, àwon ti wón bá ní Mùdínà fi ìfé hàn síwon débì wípé a rí nínú wón, enítí ó kó jáde kúrò nínú ilé rè láti lo máa wo àwòsùn kí àwon omo iyá rè tí wón wá láti Mecca ó bà lée ribi désí latar ìfé tóni siwon. Bákannaáà, a ri nínú won enití ó sofún lára àwon tówá láti Mecca pé kówò lára ìyàwó méjì tóun ni, èyí tóbáwùn jùlo nínú won, kí òun bà le kòó sílè kí ó leè bàa ráàyè fe kí onótòún yem fi ji enití ó ní obìnrin lódò.Won kò sélàjìi nítorí nnken mìrán bíkòsepé látara ifé tí wón ní sí àwom omo ìyá won tí wón wá láti Mecca. Kò tán síbè lórí òrò àwon Sàhábé Ànóbì (RA), Ní ojó kan, òken nínú won pa eran ìgbé. Enití ó pa eran yìí wá wòó wípé enití ó múlé ti òun lè mánì nnken tí won yóò jesùn nílé wón ló bá gé itan kan lára eran yìí fún alámùlétì rè yìí. Enití wón fún léran náà woó wípé àwon ti ní nnkan tí wón yóò je sùn lálé òjó náà lòun náà bá gbé eran náà fún alámùlé ti tirè náà pèlú ìròrí tí eni àkókó fi gbée fún òun. Ohun tí ó yani lénu ni wípé wón bèrè sì í gbé ran yìí fún arawon pèlú ìròrí kannáà títí tí eran yìí fi dé òdò nìkeje. Nígbàti eran náà dé òdò enìkeje òun náà ní kí òun fi eran náà se ìtore bí àwon tósíwájú rè sese. Nígbàtí òun máa fi eran náà toro, eran náà padà lo bósí owó eni tóperan tósì fi toro nígbà àkókó. Àwon Sàhàbé (RA) fìfé hàn láàrin ara won kíse wípé wón fìfé yìí hàn nìkan bísòeépé wón féràn ara won dójú ikú ni. Àwon Sàhábé (RA) lo sógun lójó kan láti gbara won kalè lówó àwon òtá tógbógun tìwón nítori Islam tí won ńfón. Nígbàtí won wàní ojú ogun yìí, òùngbe bèrè sí ní gbewón. Àwon kan nínú won sètò àti wá onì lo. Nígbàtí won gbé omi dé, wón lo gbée fún Sàhábé ken tí wón gbó pé ó ńkigbe “omi o!”. Nígbàtí wón gbé omi dé òdò rè tí ó fé gbé omi serí ó bá gbó tí òken lára won tún ńkìgbé “omi o”. Báyìí ni ó se sofún àwon tí ó gbóuni fún pé kí wón lo gbée fún enìyàn. Wón ló gbé omi fún ènìyàn lótióó. Nígbà òun náà fé gbé omi génu, òun náà tún gbó òhun elòmìrìn tí ó kígbe “omi o” ni náà bá tún ní kí wón ó lo gbé fún eni náà, Báyìí ni wón se gbé omi yìí káàkiri títí tí ó fid é orí èyan keje. Nígbàtí eni keje yìí mu omi tírè tán ní wón wá bèrè sí dá omi padà sí òdò àwon tí ó ti fé mun lákòkóó. Ohun Ìyàlénu ni yóò jè láti gbó wípé gbogbo àwon tó fé mumi lákòkóó yìí ni wón ti kú kó tó di wípé wón gbé omi pudà dé òdò won látara bóse rèwón tó àti bí wón ti ní bùkátà sóni sí. Èróúngbà won ní gbà akókótí wón gbé omi dé òdè won tí wón fí ńso wípé kí wón lo gbé omi fún omo ìyá won tí ó ń pariwo omi ni wípé òungbe tirè lásìkò yen jut i won lo. Tí a bá wo àwon òrò tí á tí ńso bò, a o rip é Èsìn Ìslàm kò fi owó kékeré mú òrò ifé. Mo pe ìwo tí o ka òrò yìí, báje kí àwa náà fi èmí ifé àti àánú se gbogbo oun tí a bá ńse tí á baà le jèrè láya àti lòrun. Mímó ni fún Oló (kúrò ní bi gbogbo oun tí wón ńfi ba wa orogún), gbogbo opé ti Olóni Bákannáà, mo wá àforíjìn àti ìtúùbá losí òdò Olórun fún gbogbo àsìse ìyówù tóle ti wáyé nínú àpilè ko yìí.