Ede Yoruba

From Wikipedia

ADEYEMO AKINLOYE STEVE

EDE YORUBA

Orílè-èdèe Yorùbá jé àti-ìran-díran odùduwà pèlú gbogbo àwon tí ń sin olórun ní ònà tí odùduwà ń gbà sìn-ín, tí wón sì bá a jáde kúrò ní agbedegbede ìwò oòrùn nígbà tí ìrúkèrúdò dé nípa ìgbàgbó rè. ÈDÈ YORÙBÁ: Nínú èdè Hausa “Yarabawa” dúró fún Yorùbá, “Yarabanci” sì dúró fún èdè Yorùbá. Nínú èdè Heberu, a rí “Yareb” àti “Yariba” àti “Yi oharib”. Títí di odún 1787, kò sí orúko kan tí a fi ń pè àwon Yorùbá lápapò. “Aku” ni wón ń pe àwon tó wá sí sàró léhìn òwò erú. Won kìí gbà kí wón pè wón ní Yorùbá. Àwon òyó nìkan ló gba orúko yìí ní orúko àpapò nígbà tí òlàjú dé. Ní odún 1917 ni òyìnbó ajélè kan gba àwon èyà yòókù níyànjú láti ka ara won kún Yorùbá kí á sì mò wón ní eya kan náà pèlú àwon ara òyó. Tí a bá wá wo èdè Hausa, èdè Heberu àti àwon èdè míràn, a lè so wípé “Èdè jé ònà bíbá ara eni sòrò ní oníran-n-ran tó sì jé pé orísìí kan yàtò sí òmíràn gédégédé. Bí a se ń so èyà èdè kan yàtò sí òmíràn. Èdè máa ń yípadà, òun sì ni esin tí “àsà” ń gùn ‘kútúpà kútúpà’. Èdè Yorùbá jé èdè abínibí àwon omo ilè káàárò o-òjíire bíi ìpínlè Èkó, Ògùn, Òyó, Kwara, Òndó, Kogi àti apá kan ìpínle Edo. Òpò ni àwon tó ń so o ni Togo, Ghana àti sàró (Sierraleone). Wón ń lò ó ni Brazil, Cuba, Jamaica, Trinidad, Tobago àti àwon erékùsù Caribbean. Òun ló sìkejì èdè tó se pàtàkì jùlo ní orílè èdè Binni (Benin Republic). Ó pèka púpòpúpò. Láti inú èka èdè wònyí ni a ti yo olórí èka èdè Yorùbá. Bí àpeere: ìró nínú èka èdè - òwò máa ń lo [gb] dípò /W/. Ondó máa ń lo [h] dípò /r/= Òrò-Ohò. Ìjèbú rémo máa ń lo [gh] tàbí [v] dípò /W/= ìwo = Ugho; Wá níbí –Va n be!. Èkejì, a rí òrò nínú èka èdè - Ìkàré máa ń pe [Oó] dípò /Owó/. Ìbàràpá máa ń pe [aláàmó] dípò/alángbá/. Ìjèbú/Ègbá/Ìgbómìnà máa ń pe [dede/gedegede] dípò/gbogbo/. Èkéta tí ó dàbí rè ni Gbólóhùn nínú èka èdè- Àkókó, Èkìtì máa ń so pé “O ò gbudò lo” dípò “O ò gbodò lo”. Ìjèbú máa ń so pé “Bosí” dípò “Níbo”. Ègbádò máa ń so pé “Ibi sí"dípò “Níbo”. Ègbádò máa ń so pé “Ibi sí” dípò “Níbo”. Ohun tí a mò ní pàtó ni wí pé: Oyèníran (1976) pín èka èdè Yorùbá sí ònà mérin WY, SEY, CY, NEY. Adétugbò (1973) pín èka èdè Yorùbá sí ònà méta NWY, SEY, CY.

ÌTÀN ÀKOÓLÈ YORÙBÁ:

Ònà méjì ni a ó gbà fi wò èyí - Ònà kìíní ni ‘Ìtàn Yorùbá’. Ònà kejì sì ni ‘Àkoólè Yorùbá’. Òpòlopò Ìtàn ni ó ti wáyé lórí ibi tí Yorùbá sè wá. Iròyìn yìí yàtò sí ara won sùgbón gbogbo won gbàwí pé ń se ni Yorùbá sí láti àríwá ìlà-oòrùn wá sí ibi tí wón tèdó sí nísisìyí. Dr. Johnson so wí pé ilè ijibiti ni Yorùbá ti sè wá. Ó fi Nimrod oba Ijibiti tó rin ìrìn-àjò omo ogun lo sí ilè Arabia láti fi se ibùgbé sùgbón tí wón lée nítorí ìjà esin. Dr Luca fara mó èrò Johnson nípa títóka sí àwon èdè Yorùbá àti ti Ijibiti tí ó papò tàbí jora.

AKIYESI:

Dr. Biobaku àti àwon egbé rè tako èrò. Dr. Lucas lórí èdè Yorùbá àti ti Ijibiti tí ó jora. Ó ní só seé se kí èdè papò nípa òwò. Ó ní à ti pé Dr. Lucas ti pón èrò rè ju bí ó ti ye lo. Dr Idowu fi èrò tirè hàn pé Olódùmarè ló rán odùduwà wá ní àsìkò ti gbogbo ayé kún fún omi. Odùduwà da iyanrìn tí olódùmarè fun láti òrun sí orí omi, eyelé wá tàn-án yíká, odùduwà àti ènìyàn mérìndínlógún wá sòkalè sí Ilé-Ifè tí ó jé orírun Yorùbá. Nígbà tí ó yá àwon Ìgbò bèrè sí fi ara hàn wón gégé bí iwin/òrò nípa dída imò òpe bora láti máa yo wón. lénu. Léyìn ìwádìí lódò òrìsà, Moremi (arewà obìnrin) yònda láti bá àwon Ìgbò lo sí ìlú won. Èyí mú kí ó ri àsírí àwon Ìgbò, ó wá padà wá láti tú àsírí náà fún àwon ènìyàn rè. Ó wá mú omo rè kan soso “Olúorogbo” láti fi rúbo sí àwon òrìsa fún èjé tí ó jé. Èrò àwon tí ó se àtúnpalè Bíbélì láti èdè Oyìnbó sí èdè Yorùbá ní nnkan bíi èéégbèwá odún (19th century) ni pé ‘àsà’àti èrò inú àwon Heberu kò yàtò sí ti àwon Yorùbá Nínú òpòlopò ìròhìn, a lè pinnu láìsiyèméjì pé àwon Yorùbá láti ibi kan wá sí Ilé-Ifè ni. Bíi èédégbèrin odún sí èédégbèfà odún ni a gbà wí pé ó jé àsìkò tí Yorùbá sí láti ibìkan wá sí Ilé-Ifè. Dr. Biobaku, léyìn òpòlopò ìwádìí rè gbà wí pé nípa àtìleyìn àwon omo Ijibiti, Heberu àti àwon kan ni odùduwà àti àwon ènìyàn rè fi dé ibi tí wón fi se àtìpó ní nnkan bíi èédégbèrin odún pèlú àkójopò òtòòtò. Adémólá Fasiku fara mó èrò Dr. Johnson sùgbón Professor J.A. Atanda tako èrò yìí, ó ní apá ìwò oòrùn ni odùduwà àti àwon ènìyàn rè ti wá. Bákan náà wón ní ìjà èsìn tó mú kí Odùduwa ní kí wón pa omo rè Bùráímò elésìn Mùsùlùmí ni ó múu sá kúrò ní ìlà oòrùn láti wá tèdó sí Ilé-Ifè níbi tí ó ti bá Àgbonmiregun (sètílù-onífá) pàdé. Lára nnkan tí wón kó dé Ilé-Ifè ni ère méjì àti àlùkùránì fún bíbo. Àwon kan so pé Òkànbí nìkan ni Odùduwà bí, àwon kan ni béè kó pé omo mérìndínlógún ni, àwon kan tún so pé méje ni. Ìtàn tí ó wá so pé Òkànbí ni ó bí omo púpò, pé méje sì ni, ni enu kò lé lórí jùlo - Olówu, Alákétu, Oba biini, Òràngún Ilé-Ìlá, Onisabe ile sabe, Olúpópó oba pópó, Oranyan ti Òyó Ilé. Ju gbogbo rè lo bí èyà kan se se àti bí wón se bá ìrìnkèrindò won dé ibi tí wón wà lónìí kò yé enikéni. Ìgbàgbó wa ni pé omo odùduwà ni gbogbo wa àti pé Ilé-Ifè ni ati sè wá. Ìsesí, Ìhùwàsí, àsà àti èsìn wa kò yàtò. Lónà kejì, àwon onímò Lìngúísíìkì se àkoólè Yorùbá Bowdich ati Clapperton lo kókó gbìyànjú kíko òrò Yorùbá sílè. Akitiyan àkókó láti gbé ìlànà àkotó Yorùbá kalè wáyé láti owó J.B. Raban (1830-1832). Akitiyan yìí ran Ajayi Crowther, Gollmer, M.D’Avezac lówó láti se àtúpalè èdè Yorùbá. Eléyìí mú kí ìjo. C.M.S. níbi tí Raban ti jé ajíhìnrere pàsè lílo èdè Yorùbá nínú ìsìn ní 1844. Ní 1824 – 1830 Hannah kilham se ìbèwò sí ìwò oòrùn Áfíríkà léèméta lórí kíko àkoto tó rorùn, tó sì já gaara. Ní 1875 asojú gbogbo ìjo pe ara won jo láti fi enu kò lórí ònà kan soso tí won yóò máa gbà ko Yorùbá sílè. Lára àwon kókó náà nìwònyí:

(i) Lábé, o, s, ìlà kékeré ni kí á fà, kì í se kíkánmo sí nídìí

(ii) ‘gb’ kìí se ‘bh’ tabi ‘b’

(iii) P (kì í se ‘kp’)

(iv) Àtòsílè àwon òrò tí wón ní édà èka-èdè, U tàbí O nínú ìró àrańmúpè. O dúró nínú àbàwón; U nínú àdánù.

(v) Òfin lílo àmì-ohùn

ÀKOSÍLÈ TI O N SO NÍPA ORIRUN YORÙBÁ

Aáyan àwon onísé ìwádìí láti topinpin àwon Yorùbá ló gbé wa lo sínú àkosílè tí ó kókó ménu bà èyà Yorùbá. Irú àkosílè béè ni a gbó pé ‘Sultan Bello’ tíí se eni tó te ìlú sokoto dó, ko sílé ní èdè Hausa. Àkosílè yìí ni Captain Clapperton nínú isé Sultan Bello tí í pe àkolé rè ní “History of the Sudan”. Sultan Bello so báyìí nípa àwon Yorùbá, pé àwon èyà tí ń gbé ní agbègbè (Yarba) jé àrómódómo omo kénáànì, tí í se èyà “Nimrodu” ó tè síwájú láti so fún wa pé ohun tí ó sín won dé ìwò oòrùn Afirika ni lílé ti Yaarooba tí í se omo Khanta lé won kúrò ní ilè Arabia sí ààrìn ìwò oòrùn láàrin ilè ifibiti si Abyssiana, àti agbègbè ibè wón tí wo ààringbùngbùn ilè Afirika wa tótí won fi i tèdó sí ibi tí won fi se ibùdó báyìí tí a mò sí ilè Yarubá èyí ní Yorùbá. Nínú ìrìn àjò won, won a fi èyà won sílè ni ibikíbi tí wón bat i dúró. Ìdí nìyen tí a fi gbà pé àwon èyà ‘Sudan tí ó ń gbé ni orí òkè orílè èdè jé èyà àwon omo Yorùbá. Ohun ti àkosílè yìí ń so ni pé ó se é se kí ó jé pé lára àwon èyà tí a mò sí Yorùbá lónìí ni ‘Sultan Bello’ ń tóka sí nínú àkosílè rè.

ÀSÀ YORÙBÁ:

Àsà ni ohun gbobgo tó je mó ìgbé ayé àwon asùwàdà ènìyàn kan ni àdúgbò kan, bèrè lórí èrò, èdè, èsìn, ètò ìsèlú, ètò orò ajé, ìsèdá ohun èlò, ìtàn, òfin, ìse, ìrísí, ìhùwàsí, onà, oúnje, ònà ìse nnkan, yíyí àyíká tàbí àdúgbò kòòkan padà. Pàtàkì jùlo èsìn ìbílè, eré ìbílè àti isé ìbílè ni a lè pè ní àsà. Ohun ti o je orírun àsà ni ‘àrà’, ó lè dára tàbí kí ó burú. Ìpolówó Èkìtì – iyan rere, obe rere; Ipolowo Ondó Ègin – (dípò Iyán) èbà gbon fee. Àsà Ondó ni kí wón máa pe iyán ni èbà nítorí pé èèwò won ni, won kò gbódò polówó iyán ni àárín ìlú. Àsà je mó ìgbàgbó àpeere; àbíkú, àkúdàáyá. Àsà je mó isé onà ti a lè fojú rí tàbí aláfenuso. A lè pín àsà sí ìsòrí méta èyí tí ó je mó:

(a) Ogbón ìmò, ète tàbí ètò tí a ń gbà se nnken, àpeere ilà kíko, irun dídì abbl.

(b) Isé onà bíi igi gbígbé

(d) Bí a se ń darí ìhùwàsí àwon egbé/èyà kan

Ara àbùdá àsà ni pé: Kò lè súyo láìsí ènìyàn; èmí rè gùn ju ti ènìyàn lo; Ó je mó ohun tí a fojúrí; Àsà kòòkan ló ní ìdí kan pàtó; Àlàyé wà nípa àsà. Àsà lè jeyo nínú oúnje: Òkèlè wó pò nínú oúnje wa. Àkókó kúndùn èbà, Ìlàje-pupuru, Igbó orà-láfún. Àsà lè jeyo nínú ìtójú oyún/aláìsàn/òkú; ètò ebí/àjosepò; ètò ìsàkóso àdúgbò, abúlé tàbí lara dídá nípa isé onà. Bí ó tilè jé pé àsà máa ń yí padà nípa aso wíwò, ìgbeyàwó abbl lóde òní ètò èkó àti ìwà òlàjú tó gbòde kan ti se àkóbá fún àsà ní ònà yìí:

(a) Ìwoso wa kò bójú mu mó

(b) Àsà ìkíni wa kò ní òwò nínú mó

(d) Kí’yàwò ilé má mo oúnje ìbílè sè mó

(e) A kò mo ìtumò àrokò tí a ń kó àwon omo wa mó.

Àwon ònà tí àsà máa ń gbà yí padà nì wònyí:

(a) Bí àsà tó wà nílè bá lágbára ju èyí tó jé tuntun lo, èyí tó wà télè yóò borí tuntun, àpeere aso wíwò.

(b) Àyípadà lè wáyé bí àsà tó wà nílè télè bá jé dógbandógba pèlú àsà tuntun, wón lè jo rìn papò, bí àpeere àsà ìgbéyàwó.

(d) Bí àsà tuntun bá lágbára ju èyí tó wà nílè télè, yóò so àsà ti àtèhìnwódi ohun ìgbàgbé, àpeere bí a se ń kólé. Tí a bá wá wò ó fínnífínní, a ri wí pé àsà lópòlopò ìtbà máa ń dá lé:

(a) Ìmò isé sáyénsì

(b) Ìse jeun wa

(d) Ìsowó kólé

(e) Isé owó ní síse

ÀKÍYÈSI:-

Èdè àwon ènìyàn jé kókó kan pàtàkì nínú àsà won. Kò sí ègbón tàbí àbúrò nínú àsà àti èdè. Ìbejì ni wón. Ojó kan náà ni wón délé ayé nítorí pé kò sí ohun tí a fé so nípa àsà tí kì í se pé èdè ni a ó fi gbé e kalè. Láti ara èdè pàápàá ni a ti lè fa àsà yo. A lè fi èdè Yorùbá so ohun tó wà lókàn eni, a lè fi korin, a lè fi kéwì, a lè fi jósìn àti béè béè lo. Láti ara àwon nnkan tí a ń so jáde lénu wònyí ni àsà wa ti ń jeyo. Ara èdè Yorùbá náà ni òwe àti àwon àkànlò-èdè gbogbo. A lè fa púpò nínú àwon àsà wa yo láti ara òw àti àkànlò èdè. Nítorí náà, èdè ni ó jé òpómúléró fún àsà Yorùbá àti wí pé òun ni ó fà á tí ó fi jé wí pé bí àwon omo Odùduwà se tàn kálè, orílè-èdè kan ni wón, èdè kan náà ni wón ń so níbikíbi tí wón lè wà. Ìsesí, ìhùwàsí, àsà àti èsìn won kò yàtò. Fún ìdí èyí, láísí ènìyàn kò lè sí àsà rárá.

REFERENCE TEXTBOOKS:

1. Adeoye C.L. (1979) Àsà àti ise Yorùbá Oxford University Press Limited

2. J.A. Atanda (1980) An introduction to Yoruba History Ibadan University Press Limited

3. Adeomola Fasiku (1995) Igbajo and its People Printed by Writers

                               Press Limited 

4. G.O. Olusanya (1983) Studies in Yorùbá History and Culture Ibadan University Press Limited.

5. Rev. Samuel Johnson (1921) The History of the Yorubas A divisional of CSS Limited.