Akewi ati Ede Re

From Wikipedia

Akewi ati ede re

ÀKÉWÌ ÀTI ÈDÈERÈ

Isé tí àwon onímò lítírésò tí gbé se lórí ewì kì í se kèrémí. Sùgbón ó se ni láàánú pé púpò ni kò sí ní àrówótó. Díè tó sì wà ní àrówótó; èdè gèésì ni wón fi ko ó fún ìdí kan tàbí òmííràn. Nítorí náà, a fúra pé a kò tíì túsu dé ìsàlè ìkòkò. Àti pé àwé-obì-kan-àjedóyòó ni isé inú ewì jé; Kò lè parí bòrò. Èbúté tí àwa fé kí àpilèko yìí gúnlè sí ni láti ya àwòrán irú eni tí a lè pè ni akéwì sí okàn àwon ònkàwé. A ó sì gbìyànjú láti júwe orísun èdè tíí máa lò àti báwo ni àbùdá rè se rí. Èyí yóò jé kí ó túbò hàn sí wa pé “isé ńlá nisé orín”. A ò sì tún mo ìyàtò tó wà láàrin “bababáwo” àti baba-aláriwo.

Ewì ni Adéagbo Akínjógbìn (1973) pè ní: “Orúko àjùmòjé tí a fún èyà àkosílè kan tí a máa ń fi ohùn dídùn so, tí a sì máa ń fi ohùn dídùn kà…” Béè ni. Sùgbón kí oríkì yìí baà lè ní ìtumò kíkún tí yóò bá àlàyé tiwa mu, ewì ni àwa ó pè ní àwon àsàyàn àsínpò-gbólóhùn aládùn tí a tí fi èdè tó pawó so di òwón, tí akéwì sì ti fi àrékun un-dá owó (nípa kíkosílè) tàbí ti ohùn re so di ogbón tó níye lórí àti ìjìnlè làákàyè lónà tí yóò fi ní ìtumò kíkún sí eni tó ń kà á tàbí eni tó ń gbó o. Ohun tí yóò fa irú ìtara yìí nip é onítòhún fura pé àwon àbápadé inú ewì náà ti inú ibú èdè, ìrírí, àsà àti àkíyèsí-ìrísí-agbègbè-eni tó je mó tàbí tí ó fara pé ti òun hù jáde. Ní òpòlopò ìgbà, kánàkò-èdè tàbí a-sun-àlàyé-kì ni àwon gbólóhùn ewì máa ń jé nítorí pé gbólóhùn kíkúrú inú won máa ń lóyún ìtumò tí yóò sì wá bímo àlàyé repete fún irúfé àwon ènìyàn tó bá mo rírì rè. Sùgbón lójú àwon ti kò bá yé (fún ìdí tí a ó ménubà níwájú) ajá ló ń gbó!!

Bí Olùfòn se fi gbogbo are jé séséefun ni ìgbési ayé ìrán yorùbá kún fún ewì. Bóyá ni a fi lè so èyí tí won ń lò púpò jù nínú ewì àti omío nítorí kò sí ìgbà tí a kì í lò ó - ojó ìpónjú tàbí ojó ayò. Ewì ni a fi n sunkún òkú kódà, ìbáà se òkú òfò. Bómodé bá kú, wón lè sunkún pé:


Moréniké lómú mi korò

O ló fomú ìyá òrun bonu

Àsàkè tòpá bò mi lójú

Ó ní ‘un tí n bá le se

Kí n máa se…

Mo té n ò dun bè.

Àgàgà bó bá jé òkú àgbà, won a ní:

Fágbénró bó ba délé

O kárá ilé

Bó o ba dónà…

Má wá pé lóko bi erú o

Má sì tètè dé bi omo òkú òle

Àsálé gbèré lomo olórò bò oko.

Nínú òrò wuuru ńkó? Àwon onítàn àròso pèlú ń yá ewì lò kí esè òrò wobn baà lè tólè. Àbí ta ni kì í pòwe? Ìsòròdorúko tí won fi ń gbé púpò nínú èdá ìtàn kalè pín lára àbùdá oríkì. Ewì sì ni. Àdán tilè ni àló lágbo lítírésò.

Sùgbón ta tilè ni Akéwì gan-an? Akéwì ni òjògbón olóhùn iyò tí ìrírí ayé rè peregedé. Etí rè kò di sí ìsèlè àdúgbò, ojú inú rè kò sì fó láti wo àtubòtán ohunkóhun Akéwì lójú òde pèlú èyí tí í fi í jérìí òrò. Ó mojú, ó mo ara. Lílo gbogbo èyà ara lónà yìí ni kì í jé kí akéwì lè sun àsùnpiyè lójókójó. Èyí ni Fálétí 91982) rí tó fi so pé:


Omi ti kò jàgbè lójú

Ó le dénú akéwì kó dòkun

Èfúùfù tó sì ń mòkun dòkun

Ó le dénú akéwì kó má jooru enu lo

Olóòrayè àti alákìíyèsí fínnífínní ènìyàn ni se pèlú. Ó béde, ó gbo èyò. E wá jé kí a máa mú àwon àbùdá wònyí lókòòkan.

Kí a tó lè so pé ènìyàn ń ké ewì, a gbódò rí kókó èkó kan pàtó kó nínú isé rè. Eni tí yóò sì dáso ró ni…Onà tí yóò fi gbé àrògún àti àròbájo rè jókòó kò gbodò tíì di gbáàtú-èyò àti méjì eépìnnì. Bátànì òtòlórìn fífi-sòrò báyìí ló fà á tí àwon olùgbón ewi fi máa ń mi orí léèkòòkan. Bí akéwì ti ń ronú ohun tí yóò kéwì lé lórí ni yóò m;aa finú ya fótò irú àwon ènìyàn tó fé ké o fún. Ó lè èka èdè won sín won je. Èwè, ó lójú irú nnkan tí a lè ké léwì ni sóòsì, ilé òòsà, ibi òkú tàbí ibi ìgbafàájì lásán. Ibùdó àti olùgbón ewì ló máa ń yan èrò àti ìlò èdè fúnra rè ìlú Oyó ni.

Gégé bi lítírésò àtenmudénu yòókù káàkiri òde àgbáyé kò sí òfin kan pàtó fún gígùn ewì Yorùbá nítorí pé síse ni won máa ń se é láré lójú agbo. Èyí mú kí ó di dandan fún akéwì láti jé eni ti kì í tijú. Won a máa se aájò sí gbogbo ìwònyí.

Òsèré àti olùdánilárayá ni àwon tí a bá pè ní akéwì, won kì í se alárògún nìkan. Àwon olùwòran dàbí alábàáse nítorí akéwì a máa gbése fún won lójú agbo. Akéwì lè má parí òrò rè délè tó jé pé àwon olùwòran ni yóò ronú bó se ye kí ó jé. Fún àpeere:

Erin ló pa kúkòyí ni

Enikan ò mò.

Kúkòyí ló pa erin ni

Enìkan ò mò

Sùgbón Kúkòyí ìbá pa erin ìbá bò


Irú isé mìíràn tí akéwì máa ń be àwon olùgbón ni títètè ronú ìtumò òwe tàbí àkànlò èdè. Bí ode kan bá so pé


Ogunlade o!

A-gbaya-lówó egbin

A-réjìká-rugi òké méfà roko

Onípèrègún igi àrígbà-yèwò.

Bí olùgbó kò bá mò pé ìbon ni igi òké méfà, ewì yìí kò le ní ìtumò. Kókó ohun tí a n so ni pé bí akéwì bá gbón féfé, olùgbó náà gbódò lánú bákan náà nítorí bí òye àwon méjééjì kò bá dógba bí omi okà tó hó sòfò ni isé akéwì yóò jo.

Isé mìíràn tí olùgbó tún ń se ni pé won a máa náwó, won a sì máa jánásì; won a sì máa gberin:


O káre

O ó jèrè

Ò o kú


Yinniyinni kéni se mìíí. E kú isé ní mórí isé yá.

Lóòótó, ohun àti èdè àbáláyè ni wón ń lò; àwon akéwì ń-sin ìrírí àtijo papó mó ti ìgbàlódé ni. Ní ìgbà mìíran èyí a máa fàáyé gba àmúlùmólà èdè. Àsà dídá sà tún wà lára onà yìí. Akéwì a máa lo èdè to tip e ti farasin tí ayé sì fé ga gbé. Fún àpeere ná-in sílífà, àdò àti béè béè lo.

Aláwáya, arinrin-un hùn-ún, asòtún-sòsi ma-ba-bikan-jé ni akewì. Bí a bá ń ló láti fi isé rè dá a léjó; ibáà se rere tàbí buburú. Mímó-ón-gé àti mímò-ón-won ló ń je béè. Enu akéwì gba òrò ni àwùjo ìran Yorùbá nítorí pé “Oba ki í pòkorin”.

Wàyi o, bawo ni èdè akáwì se rí? Ní sókí, èdè niyò ewì. Igbàgbó àti akéwi ni pé gbogbo ohun tó ba se e so lénu gbódò se é so yékéyéké tàbí so ní àsedun. Gbólóhùn a ti tún ro, tí a sì ti sun jinná korokorá. Tí jé Àwon èròjà ewi. A kò bu eran màwo bí a bá so ígbà náà pé omo tí èdè bí ni ewì jé. Sùgbón a rara pé bí a bá fi ojú bátànì sintaasi wo èhun fónrán gbólóhùn ese ewi, a lè rí ohun tó jo àsìlò níbè. Àsìlò kó, ara isé onà ni. Fún àpeere gbólóhùn ewì lè pa òrò-ìse je báyìí:


Kókó orí è (jé) egbèje

Ìlèkè ìdí è (jé) ègbèfa

Àkún owó è (jé) egbèìndínlógún


Gbólóhùn ewì a tún máa se àfikún òrò tí a fura pé kò ye kí ó wà:


Bíkú ò bá pa olùgbón

A bá so pékú járe re (ni)

Bíkú ò bá pArèsà

A bá so pékú jàre rè (ni)


Bí a ba lo asèrànwo òrò ìse bi (ki, bí, njé) láti bèrè gbólóhùn kan, a gbodo fi ìdajì gbólóhùn mìíràn gbè é lésè ni, ìbáà seèyí tó ni irú aseranwo òrò-ìse kan náà tàbí èyí tó ni sítírókísò mìíràn. Sùgbón nígbà mìíràn èwè, akéwì le to fónran ehun gbólóhùn ni àtòsódì. Fún àpeere, dípò

bí + APOR, a lè rí APOR + bi

Bi adie okoko ba je koko lagbala

Ibi omo ni fi su

Ó wá di;

Adie okoko bi o ba je”…..

Èyí fi pàtàkì adie okoko hàn jut i àkókó lo.

Àwon èdè eni tó-ti-sùn-kó-dìde ni akéwì máa ń fi lu koro pé òun gbé tuntun dé. Èyí lè jé òrò ìyanu:


E e è, e wáàá rajà omo Oba òoò

Tigi tòpè ní gbònwú àràbà

E yáa wá rajà omo Oba,

Èrò ká rebi iré gbe ń sè pòròpòrò bí omi omú.


Irú èdè dúndùn tíí ta ara àti okàn ji láti ìbèrè dé òpin gbódò lu inú ewì pa. Èyí di túláàsì kí agbo má baà túká mó on lórí. E wá jé kí a ménuba díè nínú àwon àbùdá èròjà ewì.

Nínú àfiwé, yálà elélòó tàbí tààrà ni àwon akéwì ti máa ń gbé isé fún opolo àwon olùgbó julo nítorí pé yóò nílò kí won fi èdá tàbí ìsèlè méjì wé ara won kí won sì mo ìbáré àti ìyàtò tó je yo. Ìgbà yìí ni ìtumò tó lè wáyé. Bí a bá so pé “Wèrè lòmùtí”a ti mò pé èdá kan ni wèrè, èdá mìíràn sì tún ni òmùtí. Kò ní la ni lóòógùn láti fi àwon méjéèjì wé ara won sùgbón nínú àfiwé bi i


Òpè lobìnrin

Eni tó bá ti nígbà ló ń gùn ún

Omi lènìyàn

Bó bá san síwájú.

Olùgbó gbódò mò pé orò tàbí dúkìá ni igbà dúró fún, kí ò sì mò pé kò sí ibi tí orí ò lè gbe esè èdá rè ni ìtumò ‘omi’ tó hàn nínú àpeere kejì. Àfiwé tí a kò sèsè túmò fún olùgbó tí kò sì ní ìtumò méjì tàbí èyí tó yàtò sí èrò akéwì nìkan ní kìí se àkóbá fún àsegbògo.

Ètò gbólóhùn jé ara ogbón ewì. Bí gbólóhùn inú ese ewì bá jé alákànpò tàbí àfibò, a lè to àpólà tó ye saájú séhìn. Àpeere àtúntò gbólóhùn báyìí ni


(i) Ó ń tan ara rè je

Afasé-gbèjò.

(ii) Kò gbàgbé enikan

Olórun Oba…


Onírúurú ètò báyìí ló wà: ètò olóòró, ètò oníbùú, ìfòrò-gbe-òrò, àhápin àti àwítúnwí. Àpeere ètò olóòró ni.


Ikú ń gbé ládéládé

Ikú ń ye lóyèlóyè

Ikú ń pa lákinlákin…

Àpeere ètò oníbùú ni:


E é ken lé

Ó yá ju eni a tì

Eni a tì

Ó yá ju eni a nà

Eni a nà

Ó yá ju eni a lu pa.

Àpeere òkè yìí náà lè dúró fún ifòrògbe-òrò.

Ìlò ìró wà lára èròjà ogbón ewì. Bí a bá fi ojú ìtumò wo àwon àsínpò ìró inú ewì nígbà mìíràn ìtumò won a máa fara sin. Fún àpeere


E mo dugbe àbi e ò mo dugbe?

E mo dùgbè àbi e ò mo dùgbè?

Béè mo dùgbè se be e mu dùgbèdugbe àdán…

Kó tó dàmódún towó-tomo ó ro lóòdè wa

Nítorí àbùdá èdè Yorúbà tó jé olóhùn, ònà tí a ń gba lo ìró nínú ewì pò. Díè nínú won ni:

(i) Àsínpò ìró:

Eran ìfà táya olófà kó nífà lófà Ló faya Olófà olófà kó nífà

(ii) Ifohùntakora:

Ó werin degbo réfúréfú

Kò bérin nígbó réfúréfú

Ó wérin dégbó réfùrèfù

Kò bérin nígbó rèfùrèfù


(iii) Ìró Àgbómòtumò:

Ikú pin nígbà yìí o

Ikú pin

Ikú pin làgbède sègún.

(iv) Ìfohùndárà:

Ong dowó rèng sang ong

Inang lóju’ng, ináng lénug

Ó dowó re Sàngó

Iná lójú iná lenu…

Àwon àpeere mìíràn ni ìwóhùn àti gbólóhùn dídógba. Àwon àpeere méta tó kehìn yìí lu inú Sàngó pipe pa.

Orísìí ogbón ewì mìíràn ni ewà èdè lílò. Èyí pò bí imí esú. A ti ménu ba díè léréfèé séhìn Adésígbìn (1983) si ti se atótónu púpò lórí èyi nínú ìwé Oòduà tó kojá. Díè nínú èyí tí ó ménubà ni àfiwé onírúurú, akanlo èdè, òwe, àwítúnwí abbl.

Ohun tó wá kù kí a ménu ba ni láti se àlàyé àpólà gbólóhùn kejì tó wà lára àkòrí òrò wa. Èyí ni “…èdè rè” (Akéwì àti èdè rè) ohun tí a n fi èyí tóka si ni wí pé “àdáni”ni ìsòwó èdè kan jé fún ìsòwó akéwì kan. Èyí ni pé bi a bá túmò ewì èdè sí èdè B kò ní jo ewì lójú D. Ohun tí a ń so ní pàtó ni pé iyò ewì tí a bá paláwòdà nípa títúmò sí èdè mìíràn ti di òbu pátápátá. Ta ló le mò ón pòn bí olómo!

Ìdí ni pé gbogbo ogbón tí akéwì kòòkan fi ń gbé ewì rè jókòó nínú èdè tirè kì í sáábà dógba mó ti èyà mìíràn nítorí àbùdá èdè kòòkan ti kì í papò àti ìrírí ìran omo ènìyàn ti kì í dògba. Ewì lórí ìjà esú, òwón iyò, ogun àgbékòyà omíyalé kò lè wuwo lókàn àwon Àgànyàn tó omo Yorùbá nítorí pé àwon ìsèlè yìí kò kàn wón gbòngbòn.

E jé kí a wo ibi tí èdè ti kan àtúntú ewì lábùkù nínú èdè Yorùbá pèlú Gèésì.


Ikú wá pin níugbà yìí o

Ikú pin

Ikú pin

Ikú pin làgbède sègún


Gèésì: Death has become powerless

Death has become powerless


That is what the blacksmith’s hammer says

When it struck on the anvil.


Àpeere yìí fi hàn pé ìró àgbómòtumò ti pòórá nínú àtúntú sí èdè elédè bíi gèésì. Nígbà mìíràn èwè, a kì í tilè rí òrò tó lè jé gbé-e-tán. Fún àpeere:


Ó sáré nínú igbó yelenkú yelenkú

Ó rìn ní bèbè ònà yelenkù yelenkù

Olórí asín-ìnrín dodongbá dòdòngbá…

Àtúntú a tún máa se àkóbá fún gígùn ese ewì. Kò sí bi a se lè túmò ewì kí ó má da ètò ohùn àti dídógba ese ewì rú. Fún àpeere:


i. Akinloyè – Heroism itself equals chieftaincy

ii. Pópóolá - Straight road of honour.

iii. Kóláwolé - That which brings honour into the house.

Àìdógba àsà kò ni sàìkóbá ewì tí a bá túmò sí èdè mìíràn pèlú. Bí akéwì ti n lo èhun gbólóhùn aládùn tó nnì, kò gbódò puró. Bí eni fi ìlèkùn mu ará eni lésè ni yóò jé bí akéwì bá lo hún irú ese ewì yìí mó isé rè fún omo Gèésì


i. Ìyàwó tí a fé nílé ijó

Ìran ni yóò wò lo

ii. Obìnrin ò jí kó má fìdí e hanlè

Obìnrin ò bo sokòtò

iii. Agbola ni tàgbònrín… àti béè béè lo



Nitorí wi pé iran tiwon kò ní ìgbàgbó nínú irú èrò báyìí bí a tilè túmo rè fún won lédè tí won gbó; kò ní níyi tó abéré lójú won.


E jé kí a wo ewì yìí wò.

Ajá ti n sòde rè

Ojó ti pé

Àgùntàn ti n sòde rè

Ònà jin

Kòìpé kòìjìnnà ti elédè

N sòde rè nínú eran.

Ewì yìí je mó ìtàn bí eran òsìn se wo ilè Yorùbá, èyí ti kò si lè rí béè ní apá ilè mìíràn, Irú èhun ewì báyìí ló je kí a lè so wí pé Èdá èdè àti asa je akéwì lógún púpò.

Ni ti ìlò ìró tí a ménu ba lókè. Àtúntú ewì sí èdè mìíràn yóò pa á lára. Ìdí ni pé ohùn kún ara àbùdá apààlà tí a fi ń mo èyà ewì kòòkan. Sóbò Aróbíodu so pé


Iye àèyàn tó wa nísé tísà

E fara wolúwá

E fèsè jìn.

Bí a bá ti tumò èyí si èdè mìíràn, a kò ní mò ón ni ewì Sóbò mó nítorí pé bátànì ohùn rè yóò ti pòórá.

Ayíká agbégbè tí ko papò náà wà lára ohun tó té àtúntú ewì. Bí a bá ni:

Tètè ìí té láwùjo èfó

Àlùbósà ló ní ki won ó sajú aláàánú mi jo.

Òòjó tí a bá gbé pósí wòlú

Òtòòtò èèyàn la fit a lóre.

Báwon ti a túmò ewì fún kò bá ni tètè ńkó? Bí wón tilè ní; sílébù “té” tàbí “sà” ara àlùbósà kò ní sùn le ara won bó se wà nínú èdè Yorùbá. Àbí kí a sèsè máa so nípa àwon India àti Larubawa ti won kì í lo pósí. Báwo wá ni ila 3 àti 4 òkè yen yóò se rí sí won.

Orísun ibi tí a fura pé akéwì tí ń rógbón dá ni nípa àrojinlè lóko-lódò, lósàn-án àti láàjìn. Àkíyèsí ìsèlè àti ìrísí àyíká. Àtinúdá àti àtúnro gbólóhùn. Won a máa ya èdè lò láti inú èdè mìíràn pèlú.

Ní ìparí, a ti rí i pé eni ti máa gbìyànjú láti rinú-róde ni akéwì se nítorí won máa n fi ara won sí ipò tí won bá rò pé ó ye kí olùgbó wa. Èyí ni yóò ràn wón lówó láti gbé ara won lé orí ìwòn. Èwè, a ti gbéná wo irúfé èdè tó fi ń sawo. Èyí tó sit i fi hàn wá pé bí a bá túmò ewì sí èdè mìíràn, bí ìgbà tí mààlúù múra láti lo ja gidigbò pèlú akegbé rè ni Lóńdóònù ni. Kombíìfù ni yóò bá darí wálé; esè ara rè kó ni yóò sì fi rìn bò. Bí a o ti se wo ewì mo níhìn-ín nìyí kí a máa baà di aláwòfín. Nítorí àwòfín, ló le mú òré bà jé, fírífírí lawo eni máa ń wo ni.

Abiodun Ogunwale


ÌWÉ TI MO YEWO

1. Abimbola, Wándé: An Exposition of Ifa Literary Corups, OUP, 1976 (p.99)

2. Taylor, Richard: Understanding the Element of Literature, Macmillan London, 1981.

3. Isola, Akinwumi: Ìwé Ìléwó lórí Sàngó Pípè

4. Babajamu, Malomo: Yorùbá Literature, Nigeria Publication Service, 1968.

5. Senanu, K.E. : A Selection of African Poetry Longman, 1980.


6. Àkànmú, Baba Belahu (YOL 001, oníjàálá.)


7. Olátúndé Olátúnjí: Adébayò Fálétí: A Study of his Poem, Hienemann, Educational Books Nig. Ltd., 1982.

8. Uchegbulam N. Abalugn Ed. Oral: Poetry in Nigeria, Nigeria Magazine, 1981.

9. Lijadu, Moses: Àwon Àròfò Sóbò Arobiodu Macmillan, 1976