Yoruba ati Hausa
From Wikipedia
S.L. Adesokan
Adesokan
Yoruba ati Hausa
S. L. Adésòkàn, ‘Àfiwé Àkóónú Ajemó-Èkó-Ìwà-Omolúàbí ní Àwùjo Yorùbá àti Haúsá bí ó Se Hàn nínú Orin Orlando Owoh àti Dan Maraya Jos!, Àpilèko fún Oyè Eémeè, DALL, OAU, Ifè, Nigeria.
[edit] ÀSAMÒ
Isé yìí se àgbéyèwò kókó inú orin Orlando Owoh àti Dan Maraya Jos. A wo àfojúsùn àwon òkorin méjéèjì a sì fi wón wé ara won. Ní àfikún, isé yìí wo ipa ti àwùjo kòòkan òkòòkan tí àwon orin òhún je mo n lórí re bí ó se je mó ìsédá, òkìkí àti ìtéwógbà àwon orin òhún. Nínú àwon kókó tí ó jeyo nínú áwon orin òkorin méjéèjì, a yan èkó ìwá omolúwábí ni ààyò, a si se ìtúpalè re. Lára àwon ogbón ìsèwádìí tí a lò ni síse àkójopò, àdàko àti ìtumò àwon orin òhún. A se àsàyàn ènìyàn méwàá láti inú ìpínlè merin tí ó je ti Yorùbá a si se ìwádìí lénu won nípa orin Orlando Owoh. Bákan náà ni a lo ìlànà yìí fún ènìyàn méwàá tí a yàn láti inú ìpínlè merin tí a fi òrò wá lénu wò lórí orin Dan Maraya. Gbogbo àwon èrí tí a kó jo ni a fi ìlànà tíónà tíórì ìmò-ìfíjú-ìbára-eni-gbé-pò wo lítírésò tú palè. A rí àrídájú pé àyípadà pàtàkì ti dé bá okòwò orin kíko ní àwùjo méjééjì. Ki ìmò èro tí ó jé kí ó seése fún wa láti gba orin sílè sórí káséètì to dé, léyìn tí a bá gbó orin tan ni à ń náwó fún òkorin. Ní òde òní a ó ti sanwó káséètì tí ó ní orin nínú kí ó tó wa dip é à ń gbó o. Isé ìwádìí yìí fi ìdí re múlè pé àyípada tí ó dé bá isé orin kíko ní àwùjo méjéèjì, túbò mú isé àwon òkorin méjéèjì rorùn lórí ìkóniníjanu nipa ìwà ìbàjé híhù. Ipò won yìí ba isé àwon òkorin ìgbà ìwásè mu kí ó tó dip é àsà àwon aláwò funfun so ó di ìdàkudà.
Name of Supervisor: Dr. J.B. Agbájé
No. of Pages: 272