Orin Orlando Owoh ati Dan Maraya Jos
From Wikipedia
Orin Orlando Owoh ati Dan Maraya Jos
ÀFIWÉ E HÀN YORÙBÁ ATI HAUSA BÍ Ó SLÚWÀBÍ NÍ ÀWÙJOMO-ÌWÀ-OKÓ-ÈMÓÀKÓÓNÚ AJE NÍNÚ ORIN ORLANDO OWOH ATI DAN MARAYA JOS (A COMPARATIVE STUDY OF THE ETHICAL VALUES OF THE YORÙBÁ AND HAUSA AS REFLECTED IN THE SONGS OF ORLANDO OWOH AND DAN MARAYA JOS).
SUNDAY LAWRENCE KÀNADÉSÒ
Ori Kiini
Contents |
[edit] ÌFÁÀRÀ
Ní àwùjo Yorùbá, ti a bá ń sòrò nípa músíìkì, ìlù, orin àti ijó ni ó sábà máa ń so sí ni lókàn. Bí ó tilè jé pé a lè lùlù láìsí orin, bóyá a fe túfò òkú àgbà tàbí se nnkan mìíràn, lópò ìgbá tí òrò ìlú lílù bá wáyé ni orin kíko má ń selè. Orin kíko àti ìlù lílù ni ó sábà máa n fa ijó jíjó. Ní àwùjo Yorùbá, tí a bá rí enì kan tí ó ń jó láìsí orin tàbí ìlù àwon aráyé á ní bóyá onítòhún ti fé ní àrùn opolo ni. Sùgbón ó se pàtàkì kí á rántí pé àwon onímò bí Roderyk (1975) tí ó sisé lórí ijó jíjó ti fi ìdí rè múlè pé ijó jíjó lè wáyé láìsí ìlú ti inú èdá bá dùn rékojá. Èyí sábà máa n wáyé nígbà tí òrò bá yí sí rere lórí ohun kan tí a ti so ìrètí nù lé lórí. Ní soki, èmí fara mó àkíyèsí ti Olúkòjú (1994:2-3) se pé omo inú músíìkì ni orín jé.
Nínú isé yìí, ohun tí ó je mí lógún kì í se irú ìlú tí àwon òkorin méjèèjì tí mo fé yè wò ń lù tàbí bí àwon olùgbó won se ń jó, bí kò se pé mo fé wo orin gege bí èka lítírésò kan. Orísìírísìí àrà ni a lè fi orin da bí i ti àwon èka lítírésò yòókù. Bí a se lè lo eré onítàn láti se ìkìlò ìwà, ìbániwí, ìlunilógo-enu àti béè béè lo náà ni a lè lo orin. Àkíyèsí tèmi ni pé orin kíko lè jé isé yìí ní ònà tí ó mú ni lókàn jú tí àwon èka lítírésò mìíràn lo.
Ìwé atúmò èdè Gèésì ‘Collins Dictionary of the English Language’ ti Patrick Hanks (1990:1387) se olóòtú rè gbìyànjú láti fún orin kíko ní ìtumò. Ó túmo orin sí: A piece of music usually employing text, composed for the voice especially one intended for performance by a soloist
(músíìkì tí o sábà máa ń wà ni àkosílè, tí a se fun ìfohùn gbéjáde pàápàá jùlo fún orin àdáko)
Kókó àlàyé rè ni pé kòseémánìí ni òrò ohùn nínú òrò orin kiko. Ní àkókó eni tí kò le sòrò kò le ko orin. Àkíyèsí mi lórí àgbékalè inú ìwé atúmò èdè yìí ni pé, bí ó tilè jé pé òpò àwon ohun tí ó so ni ó tònà, síbè a rí i pé omo tí ayé bí ni ayé ń pòn. Ní ayé òde òní, eni tí kò ní ohùn dídùn lè ko orin sílè fún àwon kan láti fi ohùn dídun gbé jáde. Yàto sí èyí, a lè rí eni tí ó lè sòrò télè kí ó tó di odi. Ti irú eni béè bá ní àwon orin kan lópolo tí gbogbo ayé ti mò télè, ó lè ko orin mìíràn jáde kí ó sì se àkosílè pé kí wón fi ohùn orin báyìí báyìí gbé orin tuntun òhún jáde.
Finnegan (1976:241) kò fún orin ní ìtumò. Ó sàlàyè pe orin kíko ní o wópò nínú ewì àwon aláwò dúdú. Ó ní òpò ewì kéékèèké ni ó se é ko lorin. Pataki àlàyé rè ni bí ewì se le di orin. Ó ní: It is not always recognized that these songs, in which the musical elements is of such obvious importance are in fact poems
(Kì í tete hànde pé àwon orin wònyí tí ó ní èròjà músíìkì se pàtàkì nítorí pé wón jé ewì).
O sàlàyé lórí orísirísìí ònà tí àwon orísìírísìí èyà tí ó wà ni ilè aláwò dúdú ń gbà lo orin.
Mó fi ara mó àwon àlàyé tí Finnegan (1976:241) se lori orin, sùgbón kókó àlébù isé tirè lójú tèmi ni pé, ó ye kí ó se àpéjúwé nnkan tí ó fe sòrò lé lórí kí ó tó máa so orísirísìí tí ó wà àti ìlò won.
Yusuf àti Kòfowórolá (1987:198) se àyèwò tìlùtìfon ní àwùjo awon Hausa. Ó sàlàyé pé Music is simply another element in the complexity of man’s learned behaviour. Unless people think, act and create, music sound cannot exist.
(Músíìkì tun je òkan nínú àwon ìhùwàsí tí èdá ènìyàn kó tí ó jé àmúdíjú. Àfi ti àwon ènìyàn bá ronú, tí wón se tí wón sì sèdá ni orin tó lè wáyé)
Wón gbà pé nnkan méta pàtàkì ni ó ń je kí orin kíko wáyé: Ríronú (thinking), ìse (action) àti ìsèdá (creation). Wón ní tí a bá yo owó àwon nnkan méta wònyí kúrò, kò le sí ohun tí ń jé orin. Àkíyèsí won yìí tònà, sùgbón yàtò sí pé a rí orin tí a túmò láti inú èdè kan sí èkèjì, pàápàá jùlo àwon orin èsìn, a tún rí àwon tí ó jé tí ìbílè nínú àwùjo kan tí àwon òkorin òde òní yóò kan se àyípadà sí àwon gbólóhùn inú rè lásán tí wón yóò si gbé e jáde bí orin tuntun. Fún àpeere, àwon elésìn ìgbàgbó máa ń ko orin kan pé:
Sèsè nínú mi dún
Ayó kúnnú okàn mi
Torí mó ni Jésù
Torí mó lolùwá
Torí mó ni Jésù lolúwa
Ayó kúnnú okàn mi
Ní odún 2003, léyìn tí ìbò àwon gómìnà ti wáyé ní orílè èdè yìí, Olágúnsóyè Oyinlolá di gómìnà ìpínlè Òsun. Gbajúmò eléré fújì kan, Wàsíù Àyìndé yí àwon gbólóhùn inú orin òhún padà, ó sì ko ó fún àwon olósèlú egbé ‘Peoples Democratic Party’ (P.D.P) pé:
Òyìnlòlá di gófúnó
Mà fi P.D.P. sohun rere
Ma fi yá mà fi rà
Ma fí kólé ma tómo
Lasìkò tó wá di gbómìna ilè yìí
Mà fi P.D.P. sohun rere
Àpeere orin méjéèjì jé orin òtòòtò tí a fi ohùn kan soso gbé kalè. Ó fi hàn pé kò di dandan kí èròjà métèèta ti Yusuf àti Kòfowórolá (1987:198) tóka sí péjú kí á tó ní orin. Wàsíù sèdá àwon gbólóhùn tuntun nínú orin òkè yìí, sùgbón ko sèdá ohùn òtò fúun igbéjádé rè Yusuf àti Kòfowórolá (1987:198) kò so pé orin Hausa nìkan ni àkíyèsí eléròjà méta tí àwon se je mó, orin káríayé ni ó pè é.
Ní àkótán, èmi gbà pé oríkì tí ìwé atúmò èdè Gèésì Collins Dictionary of the English Language ti Patrick (1990:1387) se olóòtú fún orin tònà pèlú àtúnse ráńpé. Èyí ni pé eni tí kò ni ohùn dídùn lè ko orin sílè fún eni tí ó ní ohùn dídùn láti ko ó fún aráyé.
[edit] Ibi Tí Agbára Isé Yìí Mo
Nínú isé yìí, tí a bá ń sòrò nípa àwùjo Yorùbá, ohun tí a ní lókàn ni àwùjo Yorùbá ti ilè Nàìjíríà. A mò pé Yorùbá wà ní ilè òkèèrè bí orilè èdè Benin, Tógò, Brazil, Cuba àti Améríkà. Nínú atótónu wa tí ó bá je mó àwùjo Yorùbá, àwon tí wón wà ní ilè káàárò o ò jíire ní orilè èdè Nàìjíríà ni a ní lókàn.
Bákan náà ni àwùjo Hausa, ohun tí a ní lókàn ni àwon Hausa tí won kò ní èdè àti àsà mìíràn ju ti Hausa lo Irú won wà ní àwon ìlú bí Kano, Daura, Katsina, Sokoto abbl ni orílè èdè Naìjíríà. A mò dájú pé ògòòrò àwon èyà kéékèèké ni won wà ní ilè Hausa. Àwon bí i Birom, Jarawa, Sayawa, Baju abbl. Gbogbo won ní èdè àti àsà tiwon lótò yàtò fún èdè Hausa tí won ń so lójoojúmó. Yàtò fún èyí, a mò pé àwon Hausa wà ní orílè èdè bí ‘Niger’, ‘Ghana’ àti béè béè lo, kìí se àwon wònyìí ni a ní lókàn.
Orin Orlando Owoh nínú isé yìí dúró fún àpeere orin àwon òkorin ilè Yorùbá ilè Nàìjíríà, kì í se ti ìpínlè Ondó tàbí ti ìlú Òwò nìkan. Orin Dan Maraya Jos ni tirè dúró fún àpeere orin àwon òkorin ní ilè Hausa, kì í se ti ìpínlè Plateau tàbí ìlú Jos nìkan.
A yan orin gégé bí èka lítírésò nínú isé yìí nítorí a gbà pé, ó jé ìlànà ìdánilékòó pàtàkì fún tomodé tàgbà ní àwùjo Yorùbá àti Hausa. Bí ètò tuntun kan bá wà tí íjoba gbé kalè fún ara ìlú, orin je òkan nínú àwon ìlànà ti ijoba fi máa ń so fún àwon ènìyàn.
Kókó òrò tí Orlando Owoh àti Dan Maraya Jos sòrò lé lórí nínú orin won pò jojo. Bí àpeere òrò òsèlú, ogun abélé, igbó mímu, tété títa, ìtàn síso àti béè béè lo. Àwon tí ó je mó èkó ìwà omolúwàbí ní àwùjo Yorùbá àti Hausa ni ó je wá lógún nínú isé yìí.
Léyìn tí a se àsàyàn àwon orin tan, kókó tí ó je mo ìwà omolúwàbí lábé ìsòrí méwàá ni a gbé yè wò. Àwon ìsòrí méwèèwá òhún ni Òtító síso, Ìtélórùn, Sùúrù, Ìfé, Ìsètó-Fómo-Enìkejì, Ríran aláìní lówó, ìtéríba, ìbòwò fun òbí àti àgbà, ìbòwò fún àsà àti ìse àwùjo àti isé síse. Òrò tí ó je mó ìhun àti ìlò èdè nínú orin Orlando Owoh àti Dan Maraya Jos kò je wa lógún nínú isé yìí. Bákan náà, ìlànà ìgbékalè orin àwon méjèèjì kò je wá lógún. Akóónú orin àwon òkorin méjèèjì nìkan ló je wa lógún.
[edit] Èròngbà Isé Yìí
Èròngbà márùn-ún ni a ní lórí isé yìí. Àkókó ni láti se àsàyàn díè nínú àkójopo orin Orlando Owoh àti Dan Maraya Jos. Èyí ni yóò jé kí a rí orísìírísìí àwon kókó tí wón ménu bà, kí á to wa se àsàyàn.
Àsàyàn tí mo fé se yìí jé àwon orin tí ó ní àkóónú tí ó je mó èkó ìwà omolúwàbí. Nnkan kejì ni pé a fé wo àwon kókó tí ó jé pàtàkì nínú akitiyan àwon méjèèjì nínú ìgbìyànjú àti dá àwùjo won ní èkó ìwà omolúwàbí.
Nnkan keta ni pé a fé wo àwon ìjora àti ìyàtò tí ó wà nínú àwon kókó ídánílékòó ìwà omolúwàbí, bí ó se je jade nínú orin àwon méjèèjì. Ó se pàtàkì kí á rántí pé òrò èdè àti lítírèsò rè dà bí apá méjì tí eye fi ń fò ni, bí ó tilè jé pé a lè rí àwon isé tóka sí nínú ìmò nípa èdè pàápàá jùlo kókó tí ó je mó èdé àyálò láti inú èdè kan sí èkejì lórí òrò èdè Yorùbá àti Hausa, kò sí isé pàatàkì tí ó fí hàn wá pé kì í se orí òrò àyálò èdè nìkàn ni ìbásepò yìí ti wáyé. A se àkíyèsí pé àwon òkorin Yorùbá kan títí kan Orlando pàápàá máa ń fi èdè Hausa korin Bákan náà ni àwon òkorin Hausa kan máa n fi èdè Yorùbá korin. Nínú orin kan ti Orlando pe àkolé rè ‘No money No friend’ O fi èdè Hausa korin pé
Kudi ya zo
Mata ya zo
Kudi ya kare
Mata mata mata banza
Èyí túmò si pe
Bí Owó bá dé
Ìyàwó á dé
Bí owó bá tán
Ìyàwó a dìyàwó lásánlàsàn
Bí ó tilè jé pé Hausa Orlando kò dánmórán. Ohun tí ó ní lókán gégé bí ó se ko orin òhún ní èdè Yorùbá ni pé bí nnkan bá ń dùn yùngbà, obìnrin á dúró, tí àyípadà burúkú bá dé obìnrin á sálo. Síbè, ohun tí ó ní lókàn ti yé àwa olùgbó rè.
Àpeere àwon òkorin Hausa tí won ń gbìyànjú láti fi èdè Yorùbá korin ni ti Sálísù tí o bá Músílíù Ìsòlá ko orin èfè nínú orin tí ó pè àkolé rè ni ‘Authentic’
Dán Mùsùkú
Mùsùkú mùsùkú mùsùkú
Jókòó daadaa
Olorun yóò se daadaa
E ni soríburúkú
Omo àlàlàkibò
Kíbòrokì
Òbòròbò fi si
Se ó dàroo
Iwájú iwájú
Fi sí i léyìn leyìn
E nì soríburúkú à dúníyàn
Àwon omo Yorùbá kan tilè gba èsìn mùsùlùmí bí i ti àwon Hausa. Bí òrò báà rí báyìí, ó di dandan kí a rí àwon àpeere ibi tí àjosepò yóò ti wáyé nínú àsà àti ìse títí kan lítírésò won Nnkan kerin ni pé mo fé wo bí òkorin kòókan se ń fi orin rè se isé alóre lórí èkó ìwà omolúwàbí nínú àwùjo tirè. Ó hàn pé isé àwon onílítírésò lélékajèka ni bíbu enu àté lu àwon ìwà tí kò tó nínú àwùjo, kí wón sì lu àwon tí wón se rere lógo enu. Nnkan méjì ló ta mí jí láti sisé lórí kókó òrò yìí. Èkíní ni pé Orlando Owoh jé gbajúmò òkorin kan ní ilè Yorùbá tí ó ní àwon nnkan kan tí ó yà á sótò sí àwon òkorin yòókù. Òun ni òkorin tí ó gbajúmò jù nínú àwon tí won ń lo èka èdè Òwò nínú àwon orin won Nnkan kejì ni pè mo se àkíyèsí pé nínú òpòlopò isé alákadá tí àwon onísé ìwádìí ilè Yorùbá ti se, apá ibi tí èdè Yorùbá àti Hausa ti kolura nípa àyálò èdè lábé ìmò nípa gírámà ni ó hànde jù. Kò sí ìgbìyànjú kankan láti wádìí bóyá ìjekanra wà nínú èka lítírésò, pàápàá orin kíko. Ìmólè tín-ín-tín tí ó tàn sí apá ibí yìí ni ìgbìyànjú àwon olórin Yorùbá kan láti fi èdè Hausa ko orin tàbí kí wón fi gbólóhùn Hausa díè sí inú orin won. Àpeere wà nínú orin Bàrísítà Àyìndé, Kollington Àyìnlá àti Orlando Owoh fúnra rè.
[edit] Ogbón Ìsèwádìí
Ònà tí a gbà se isé yìí ni pé a se àsàyàn kókó òrò méwàá tí ó je mó èkó nípa ìwà omolúwàbí ní àwùjo méjéèjì. Nnkan kejì tí a se ni pé a se àsàyàn márun¬-ún márùn ún, nínú orin Orlando Owoh àti Dan Maraya Jos. A gbìyànjú láti se àwárí àwon ònà ti Orlando ti sòrò lori kókó kòòkan nínú àwon àsàyàn orin tí ó je tirè. Bákan náà ni a se fún orin Dan Maraya Jos.
Abala méta ni àwon àlàyè tí ó je mó isé ìwádìí yìí pín sí. Ònà kìn-ín-ní je mó bí a se se àkójopò, àsàyàn àti àdàko orin Orlando Owoh àti Dan Maraya Jos.
Ònà kejì je mó bí a ti se àsàyàn àwon ènìyàn méwàá, méwàá tí wón je olólùfé òkorin kòòkan àti kókó ohun tí a fi òrò wá won lénu wò lé lórí.
Abala keta je mó òrò tíórì tí a fi se ìtúpalè. Àwùjo Yorùbá ni a wò láti fi se ìtúpalè isé Orlando Owoh nígbà tí a wo àwùjo Hausa fún ìtúpalè isé Dan Maraya Jos.
Láti se àkójopò orin Orlando Owoh, a ra káséètì orin Orlando bí márùndínlógbòn. A gbó won dáradára. Léyìn èyí ni a se àsàyàn àwon tí ó je mó èkó ìwá omolúwàbí. A ka àwon àdàko orin rè tí Akínmúwàgún (2001) se, a si se àsàyàn eyo méjì tí ó je mó èkó ìwà omolúwàbí, a si se àdàko won.
Láti se àkójopò orin Dan Maraya Jos, a rí òpòlopò àwon awo orin kéékèèké tí ó jé ti Dan Maraya Jos tí wón ti gbà sílè sórí fónrán káséètí pèlú àdàko won ní èdè Hausa ní èka ti wón ti ń kó nípa àsà ilè Nàìjíríà ni Yunifásítì Ahamdu Bello tí ó wà ní Zaria, ìpínlè Kaduna (Music library of Centre for Nigerian Cultural Studies at Ahmadu Bello University, Zaria). Léyìn èyí a se àsàyàn díè¸lára àkójopò àti àdàko orin rè tí Habib (1973) se ní èdè Hausa.
Láti se àdàko orin Orlando, a se àdàko won láti inú fónrán káséètì. A se alábàápàdé àwon òrò kòòkan tí wón jé èka èdè òwò. Níwòn ìgbà tí kò sí ìwé atúmò fún èka èdè Owo, a wádìí ìtumò òrò kòòkan lénu abénà-ìmò meta. Àwon méjì àkókó jé omo bíbí ìlú Òwò, tí wón gbé ìlú Owo dàgbà, won kò dín ní omo àádota ódùn. Enìkan yooku je omo ìlú Ibadan tí ó ti gbé ìlú Òwò fún nnkan bí ogbòn odún ó lé díè. Àkíyèsi wa ni pé kò sí ìyàtò kankan nínú ìtumò tí àwon métèèta fún àwon òrò ti a se ìwádìí lé lórí.
Láti se àdàko orin Dan Maraya Jos, láti inú èdè Hausa sí èdè Gèésí, a gbé isé yìí fún àwon ènìyàn méjì. Eni kín-ín jé olórí èkó èdè Hausa ti ilé-ìwé olùkóni àgbà tí ó jé ti ìjoba àpapò tí ó wà ní ìlú Katsina. Eni kejì jé olórí èka èkó èdè Géèsì tí ilé èkó kan náà. Omo Hausa ni àwon méjèèjì, ìlú Katsina ni wón sì gbé dàgbà Isé àwon wònyí pèlú ìmò díé tí èmi pàápàá ni lórí èdè Hausa ni mo lò láti se ìtumò àwon orin Dan Maraya Jos sí èdè Gèésì. Láti se àdàko láti èdè Gèésì sí èdè Yorùbá, mo gbìyànjú láti se Ise yìí pèlú ìmòràn àti ìtósónà láti odo olórí èka èkó èdè Yorùbá ti ilé ìwé olùkóni àgbá tí ó wà ní ìlú Katsina. Onímò èdá èdè ni alàgbà yìí.
Láti se àsàyàn àwon abénà-ìmò méwàá méwàá tí a fi òrò wá lénu wò ohun tí a kóko se ni láti se àsàyàn ìpínlè mérin mérin tí a ti fé se ìfòròwánilénuwò. Ònà tí a gbà se àsàyàn ìpínlè ni pé a ko orúko ìpínlè kòòkan ti Yorùbá ti jé onílé àti onílè sí inú ìwé pélébé pélébé. A ra àwon ìwé wònyìí ródóródó a sì dà wón sí inú agolo ńlá kan. A gbìyànjù láti se àsàyàn nípá kíki owó bo inú agolo yìí láti mu eyo kan jáde léèkansoso. Tí a bá ti mú òkan jáde, a ó tú u wò a ó sí kò orùkó ìpínlè tí o wà nínú rè sílè. A se báyìí ni èèmerin. Àbájádé ìyànjú yìí ni pé a rí ìpínlè Òyó, Òsun, Ondo àti Ògùn. Bákan náà ni a se fún yíyan ìpínlè tí àwon Hausa ti jé onílé àti onílè. Àbájáde ìyànjú yorí sí yíyan ìpínlè Katsina, Kano, Sokoto àti Kaduna.
Láti se àsàyàn àwon abénà-ìmò méwàá méwàá, a lo sí olú ìlú (capital) àwon ìpínlè wònyí. A wá ojà tí wón ń ná ní ojoojúmó ní ibè. Nínú ojà yìí ni a ti se ìfòròwánilénuwò. Ohun tí a se ni pé ìpínlè ti a bá kókó yàn, ènìyàn mérin mérin tí ó jé obìinrin mejì, okùnrin méjì ni a fi òrò wá lénu wò. Léyin èyí, nínú gbogbo àwon ìpínlè tí ó bá jé àtèlé ènìyàn méjì méjì, okùnrin kan, obìnrin kan ni a fi òrò wá lènu wò. Kókó ohun tí a bí won ni ìdí tí wón fi féràn àwon òkorin wònyí àti ipa tí orin won ti kó nínú ìgbésí ayé àwon olùgbó. Se ni a kókó gba ìfòròwánilénuwò lórí Dan Maraya Jos ní èdè Hausa sí orí fónrán káséètì ki á tó wá se ìtumò pèlú ìrànlówó àwon abénà ìmò.
Ònà tí a gbà se àyolò ibi ìjeyo kókó òrò nínú àsàyàn orin ni pé, mo fi káséètì orin kòòkan se àsomó kòòkan. Àsomó márùn-ún àkókó (Àsomó 1-5) je ti àwon káséètì Orlando Owoh, nígbà tí àwon márùn-ún tí ó gbèyìn (Àsomó 6-10) jé¸ti káséètì orin Dan Maraya Jos. Bí a bá fé se àyolò kan, a ó kàn dárúko nómbà àsomó òhún, ojú ìwé tí àyolò bó sí àti ìlà tàbí àwon ìlà tí àsomó òhún ti jáde. Fún àpeere Àsomó I, 0.i 10 ìlà 4-8 dúró fún Àsomó kìn-ín-ní tí ó wà ní ojú ìwé kewàá, ílà kerin sí èkejo.
[edit] Tíórì Àmúlò
Orísìírísìí ìyànjú ni àwon ènìyàn ti gbà láti sàlàyé ohun tí tíórì jé. Ìwé atúmò èdè Oxford Advanced Learner’s Dictionary of Current English ti A. S. Hornby (1985:896) túmò tíórì si Reasoned supposition put forward to explain facts or events
(Àròjinlè lórí i bo-se-ye-kó-jé ti a gbé kalè láti sàlàyé àwon àkíyèsí tàbí ìsèlè kan)
Èyí túmò sí síse àlàyé ìdí abájo nnkan tàbí ìsèlè kan.
Àjàyí (1997) se atótónu lórí òrò tíórì. Ó ní òye tí ó jé ìlànà kan sàn-án tí à n tèlé ní síse ohun kan ni. Òpéfèyítìmí (1997) gbìyànjú lati pìtàn tíórì láti orírun rè kí ó tó dé inú èdè Yorùbá. Ó ní Yorùbá ya òrò náà lo láti inú èdè Gèésì ni, béè àwon Gèésì pàápàá yá a lò láti inú èdè Gíríìkì ni. Kókó àlàyé rè ni pé, lójú àwon Gèésì, òrò tíórì je mo èrò ni, ko kan àmúse.
Àlàbí (2003:142-144) kò tilè se àlàyè kan gúnmó ní orí ìtumò tíórì. Ó mú orísi tíórí merin lò láti sàlàyé àwon ònà tí omodé ń gbà láti kó èdè síso. Nínú àlàyé rè lórí òkòòkan àwon tíórì òhún, ó hàn pé àlàyé lórí àwon orísìírísìí ònà tí a lè gbà se nnkan ni.
Àlàyé díè ti àwá lè se lórí ìtumò tíórì ni pé sàsà ni àwùjo tí kì í lo tíórí. Ànfààní àsà mò-ón-ko mòn-òn-kà tí àwon Gèésì ní àti ìmò èrò (technology) tí wón fi ń tan èrò won káàkiri ló fún won ní àanfààní tí ó fi dà bí eni pé àwon ni wón bèrè ìlò tíórì.
Ní àwùjo Yorùbá, a lè ní abúlé kékéré kan tí odò ti sàn kojá. Omodé tó jí lo sí odò lè so fún àwon ará ilé pé odò ti kún gan-an. Ní kia, ohun tí ó so yóò ti yé àwon ará ilé láìdé odò. Báwo ni omo se mò pé odò kún? Ó ní láti jé pé lásìkò tí kò bá sí òjò tàbí òdá, ó ní ògangan ibi tí irú omi odò béè máa ń mo. Tí òjò bá pò tí omi ju ibi tí ó mo télè, a gbà pé odò ti kún. Bí òdá bá dá tí omi yìí kò dé ibè a ó so pé odò ti fà. Nínú atótónu òkè yìí, òdiwòn ni à ń se. Láìsí tíórì tàbí òdiwòn tí ó jé àjomò láàrin asafò àti agbafò, àlàyé òrò kò le tètè ní ìtumò sí eni tí à ń se é fún. Àwon ìsèlè àti ìhùwàsí wà lórísirísìí nínú orísirísìí àwùjo. Àwùjo kòòkan ní òfin tirè, orí odiwon àwon òfin wònyí ni òrò ohun tí o dára àti ohun tí kò dàra ti je jáde. Àwon òkorin a máa wo àwon ìsèlè àti àwon ìhùwàsí kan ní àwùjo. Won á sì so èrò okàn won lórí re. Won a tilè máa mu ìmòràn wá.
Nínú àlàyé òkè yìí, ó hàn gbangba pé àwon ìsèlè àti ìhùwàsí inú àwùjo ni o máa ń so kókó ohun tí àwon òkorin yóò fi orin won so. Ó di dandan kí á mo àsà àti ìse irú àwùjo béè kí isé òkorin béè tó lè ní ìtumò sí wa. Èyí ni ó fà á tí a fi yan tíórì ìmò ìfojú-ìbára-eni-gbépò-wo-lítírésò láàyò gégé bi tíórì láti se ìtúpalè isé yìí.