Efon-Alaaye

From Wikipedia

Efon-Alaaye

Ìtàn Ìsèdálè Ìlú Èfòn-Aláayè Láti owó I.A. Ologunleko, DALL, OAU, Ifè, Nigeria

Nínú àwon ìwé ti mo yè wò. kò sí èyí tó so pàtó ìgbà tàbí àkókò tí a dá ìlú Èfòm-Aláayè sílè. Gégé bí ìse àti àbúdá ìtàn ìwásè. púpò nínú ìtàn yìí ló máa ń rújú pàápàá tó bá jé ìtàn ìtèlúdó ni ìle Yorùbá. (Akínyemí 1991:121) Ìlànà ìtàn àròso ìwásè ní a gbé ìtàn wònyí lé. Ní ìgbà ìwásè kò sí pé a ń ko nnkan sílè. Nítorí àìko sílè ìtàn yìí, kò jé kì a rí àkosílè gidi fún òpòlopò ìlú ní ilè Yorùbá nínú ibi tí ìlú Èfòn-Aláayè ti jé òkan nínú awon ìlú béè. Ìtàn ti a rí jójo kò kojá ìtàn atenúdenu. ìtàn ìwásè ìlú Èfòn Aláayé kò yàtò sí èyí. Orísìí òpìtàn ni a rí, ìtàn won máa ń yàtò sí ara won, bí kò ní àfikún yóò ni àyokúro òkan pàtàkì lára ohun tí àwon òpìtàn ti sisé lé lórí nípa ìtàn ilè Aáfíríkà ni ìyànjú won lati wo ìtàn ìwásè, kí wón tó lè fa òótó yo jáde. Sàsà ni onímò kan tó sisé lórí ìtàn ìlú kan tàbí àdúgbò kan tí kò mú ìlànà ìtàn ìwásè ló láti sàlàyé to bojumu nípa orírun ìlú kan (Johnson 1921;3).

Gégé bí àwon òpìtàn ilè Yorùbá, àwo òpìtàn ìlú Èfòn Aláayè gbà pé òdò odùduwà ni wón tí sè wá láti Ilé-Ifè. Lára àwon òpìtàn yìí tilè lérò pé eni tó te ìlú Èfòn-Aláayè dó rò lati ojú òrun sílé ayé. Ìlú tó sòkalè sí ní Ilé-Ifè tó jé orírun àwon Yorùbá. Ìtàn yìí sòro láti gbàgbó, nítorí kò ri ìdí múlè. Kò tí ì sí eni tí a rí tó wò láti ojú òrun rí. Nínú ìtàn ìwásè, òrìsà àti odù mérìndínlógún ni a gbó pé wón rò láti ìsálòrun wá sí ìsálayé (Abimbola, W. 1968:15). Awon òpìtàn yìí lè rò pé bóyá nítorí tí a ti ń pe àwon Oba ilè Yorùbá ni ìgbákejì òrìsà ni àwon náà se rò pé Aláayè àkókó rò sílé ayé lati òrun.

‘Omo owá, omo ekún

Omo òkìrìkìsì

Omo ò tójú òrun á yé’

Nínu ìtàn ìwásè mìíràn, a gbó pé Obàlùfòn Aláyémore ni oba àkókó ti o te ìlú Èfòn-Aláayè dó. Obalùfòn Aláyémore yìí jé omo Obàlùfòn Ogbógbódirin tí í se àkóbí Odùduwà tí ó jé Oòni ti Ilé-Ifè ni àkókó ìgbà kan. Léyìn Ikú rè, Òrànmíyàn lò ye kí ó je oba ní Ilé-Ifè sùgbón ó ti lo sílùú àwon omo rè, Eweka ni Eìní ati Aláàfin ni Òyó. Obàlùfòn Aláyémore ti je oyè Oòni kí Òrànmíyàn tó dé.

Nígbà tí Òrànmíyàn dé, Aláyémore sá kúrò lórí oyè nítorí pé ní ayé àtijó won kì í fi eni ìsááju sílè láti fi àbúrò joyè. Obàlùfòn Aláyémore rìn títí ó fi dé orí òkè kan. Won pe ibè ni Oba-òkè. Èyí ni oba tó tèdó sorí òkè sùgbón lónìí òbàkè ni won ń pe ibè.

Ni orí òkè yìí, Obàlùfòn se àkíyèsí pé eranko búburú pò ní agbègbè tó tèdó sí, èyí tó pòjù ni efòn. Ó bèrè sí í pa efòn yìí ni àparun. Awon efòn kékeré níbè ni won kójo sínu ogbà, ti won so won mólè títí wón fi kú. Omodé tó bá lo sì igbó ibi tí wón kó efòn kékeré sí, ni awon òbí won a ké pé: ‘Kó ò yàá se lúgbó efòn alaayè’

Nibi yìí ni Èfòn ti kún orúko Obalufon Aláyémore. Lára Aláyémore ni won tí yo Aláayè to fid i: Èfòn-Aláayè títí dí òní. Nígbà tí ó se Obàlùfòn Aláyémore ránsé sí Òrànmíyàn kí o fi nnkan ìtèlúdó sowó sí òun. Léyìn tí wón ti fi nnkan yìí ránsé sí Obàlùfòn Aláyémore; kò pé ti Òrànmíyàn kú. Àwon ará Ilé-Ifè wá ránsé si Obàlùfòn Aláyémore láti wá joba léèkejì. Kí o tó lo, ó fí omo rè joba ní ipò rè. Ìyàwó méta ni Aláyémore ni kí ó tó kúrò ní Èfòn-Aláayè. Àwon ni Adúdú Òránkú tí ì se ìran àwon Obólógun; Aparapára òrun ìran awon Asemojo, èèketa ni Èsùmòrè-gbé-ojú-òrun-sàgá-ìjà. Ìtàn so pé lásìkò tí Obàlùfòn Aláyémore padà sí Ilé-Ifè gégé bí Oòni, bó sí àkókò ti Oba Dàda Aláàfin Òyó wá lórí oyè ni nnkan bí 1200-1300AD. Bí ìtàn ìwásè yìí ìbá se rorún tó láti gbàgbó awon àskìyèsí kan ní a rí tóka sí tí ó jé kí ìtàn náà rú ènìyàn lójú. Nínú ìtàn yìí, won so pé Obàlùfòn Ògbógbódirin ni àkóbí Odùduwa, èyí tó tako ìtàn tí a ti mò télè nípa Odùduwa. Òkànbí ni àkóbí Odùduwa. Bó bá tilè se orúko ló yípadà, àwon omo Okànbí ni oba méje pàtàkì ni ilè Yorùbá tí kò sí Obàlùfòn nínú won. Ohun tí òpìtàn ìbá so fun wa nip é ìran Odùduwà ni Obàlùfòn jé.

Àkókò tí ìsèlè yìí se rú ni lójú púpò. Nínú ìtàn yìí a ri i pe Obàlùfòn Aláyémore mo àsìkò ti Òrànmíyàn wà láyé. A rí i pé ègbón àti àbúrò ni won. Kó ye kó rí béè, se ló ye kó je omo àti bàbá. Lóòótó ni Òrànmíyàn je oba ni Òkò, tó tún wá sí Ilé-Ifè. Àwon ará Òy;o ló fi Àjàká je oba sí Òkò. Aláàfin Dada tí òpìtàn fenu bà pé ó je oba ní Òyó da ìtàn rú. Johnson (1921:144) gbà pé Àjàká ló wá lórí oyè gégé bí Aláàfin Òyó nígbà tí Òrànmíyàn kú. Tó bá jé òtító ní Obàlùfòn Aláyémore tún wa joba léèkejì ní Ilé-Ifè a jé pé àsìkò Aláàfin Àjàkáló je oba.

Awon òtìtó kòòkan farahàn nínú ìtàn yìí. Lóòótó ni Obalùfòn Aláyémore kan wá ni Ilé-Ifè. Títí dí oní ògbón Obàlùfòn wa ní Ilé-Ifè. Àdúgbò Aláayè si wa ní Ilé-Ifè títí dí òní. Kò sí iró níbè pé Èfòn Aláayè bá Ilé-Ifè tan. Nínú ìtàn mìíràn, a gbo pé àwon orísìí ènìyàn bí i méfà ni wón tèdó lásìkò òtòòtò sí Èfòn-Aláayè. Nínú ìtàn yìí, a gbó pé Èkúwì ló kókó dé sílùú Èfòn-Aláayè, igbó-àbá ni Èkúwì tèdó sí. Ode kan tí orúko rè ń jé Oríkin náà tèdó sí Igbó àayè. Lójó kan, lásìkò tí oríkin tèdó, ó rí iná tó ń rú ni Igbó-Àbá. Ó se òde lo sí igbó yìí. Oríkin ro àwon tó wa ni Igbó àbá kí won jo má gbé ní Igbó-Àayè. Wón gbà béè. Lásìkò tí won jo ń gbé ni won fí Obàlùfòn je oba. Igbákejì Obàlùfòn tí wón jo wá láti Ilé-Ifè ní won fi je igbákejì oba tí a mò sí Obańlá. Bàbá Igbó Àbá ojósí ni won fi je baba olójà tí a mo sí Obalójà. Obàlùfòn àti Obalójà jé òré tímótímó nígbà náà. Bí oba se ń pàse fún àayè ní Obalójà se n pàse ní Òbàlú láyé ìgbà náà. Lónìí, Obalójà je Olóyè pàtàkì ní ìlú Èfòn. Obalójù ní olórí àwon Òbàlú. Àjose wá láàrìn Oba àti Obalójà. Bí oba kan bá wàjà ní ìlú Èfòn-Aláayè, iwájú ilé oba-olója ni won yóò kó ojà lo.

Nínú ìtàn mìíran a gbó pé ààfin Odùduwà ni wón bí Aláayè sí. Òkan nínú àwon omo-oba obinrin ló bii. O jé arewà okùnrin ti ènìyàn púpò féràn rè pàápàá àwon babaláwo tó ń wá sí ààfin. Ìtàn yìí tèsíwájú pé okùnrin yìí ní aáwò ni ààfin, èyí ló mú kí Odùduwà se fún Aláayè ní ilè sí ìráyè tí a mò sì Modákéké lónìí. Odùduwà fún un ni adé tó sì n jé Oba Láayè. Nínú ìtèsìwájú, Ìtàn mìíràn tó fara jo ìtàn òkè yìí, a gbó pé àwon omooba méjì ló fé lo te ìlú dó. Bó ba rí béè á jé pé ìlú Èfòn tí wá kí Modákéké tó dáyé. Àtàdá ati Johnson tilè maa ń to Aré àti Èfòn tèlé ara won.

Ni pàtàkì, ogun kò según Èfò Aláayè rí àyàfi Ogun Odérinlo (1852-54). Odérìnlo je omo Ìrágberí, béè ni Èfòn-Aláayè ni ìrágberí ti kúrò. A le so pe omo bíbi Èfòn ló kó Èfòn-Aláayè kì í se òtá nítorí òkè to yí wón ká je ìrànlówó púpò fún ìlú Èfòn-Aláayè, ó sì je wàhálà fun òtá. Àwon òtá to fe jà won lógun nígbó Òòyè, won se lásán ni. Ogun yìí fà á ti Aláayè kì í fi je osun ògògó titi dòní. Ohun àrífàyo nínú ìtàn yìí nip é ode ló te ìlú Èfòn dó gégé bí àwon ìlú mìíran ni ilè Yorùbá. Léyìn rè ni àwon mìíràn ń tèlé e wá sí ibi ìtèdó. Ó se é se béè nitori ibi ti ode máa ń tèdó sí kò ní jìnnà sí omit i ń sàn; àtipé yóò ti kó àwon eran rè jo sí ojú ibi ìdáná. Oja ló séyo láti ibè. A tún rí i pé eni tó je oba Èfòn gbé adé rè wá láti Ilé-Ifè; sùgbón àsìkò tó dé sí ibùdó yìí ni a kò mò. Lóòótó, eni tó bá jé alágbára láyé àtijo, tó sì ní àmúye ni won fi i joba, léyìn ti Ifá bá ti fore. Kò yá wá lénu pé wón fi eni tí adé ń be lówó rè je oba nítorí àwon ohun àmúye oba wà ni sàkání rè.

Ní ìparí, Finnegan (1970:368) so nínú oro re pé: …they (myths) depict the deeds of human rather then supernatural heroes and deal with or allude to, events such as migrations, war, or the establishment of ruling dynasties.

Èyí ni pé ìtàn ìwásè jé ohun tí ó selè ti pé, ó ń so nípa ènìyàn akoni àti awon nnkan to yi i ka bí ìrìnàjò láti ibi kan sí èkejì, ogun jíjà ati bí won se te ìlú dó. Encyclopaedia Britanica (1960:54) sàlàyé pé ìtàn ìwásè jé ìtàn nípa àsà tí ó ń sàlàyé nípa ènìyàn, eranko, òrìsà àti èmí àìrí. Irú ìtàn yìí kì í so àkókò gan-an tí ìsèlè sé sùgbón won jé kí ìtàn ní kókó àti ìsèlè tí a kò lò rí nínú ìtàn lásán. Ìtàn ìwásè máa ń je ònà kan pàtàkì láti sàlàyé ìgbé ayé tó ti kojá. Ò máa ń so nípa bí àwon ènìyàn se dé sí ilè kan ati ìdí tí àwon kan fi je gàba lórí àwon egbé rè. Volume Library (267) tilè so pé o ye kí ìgbàgbó wa rò mó ìtàn ìwásè nítorí ó jé mó àsà bí o tile jé pé kò sí eni tó mo ìbèrè ìtàn béè sùgbón ohun ti a mò nip é ìtàn ìwásè ti wáyé lásìkò tó ti pé.

A kò lè fówó ró ìtàn ìwásè ìlí Èfòn-Alàayè séyìn, bí ó tilè jé pé nínú àwon ìtàn tí àwon òpìtàn so fún wa, ìdásoró okùn-ìtàn wà níbè sùgbón nnkan tó se pàtàkì ní pé eni tó te ìlú Èfòn Alàayè dó wá láti Ilé-Ifè ní àsìkò ìgbà kan tí a kò mò. Ìlú ibi ti wón tèdó sí tù won lára, wón sì ń gbé ibè títí dí òní.

Àkíyèsí: A yo isé yìí láti inú àpilèko fún Oyè Émeè I.A. Ologunleko.