Isedale Yoruba
From Wikipedia
Isedale Yoruba
Ìtàn Àkoólè Yorùbá
Gégé bí ìwádìí Àtàndá (1980), bí àwon Yorùbá se dé orílè-èdè Nàìjíríà àti àsìkò tí wón tèdó síbè kíi se ìbéèrè tí enikéni lè dáhùn ní pàtó nítorí pé àwon baba nlá won kò fi àkosílè ìse àti ìtàn won sílè gégé bí àjogúnbá.
Àwon ìtàn àtenudénu tí a gbó nípa ìsèdá yàtò sí ara won díèdíè. Ìtàn kan so fún wa pé àwon Yorùbá ti wà láti ìgbà ìwásè àti láti ìgbà ìsèdá ayé. Ìtàn òrùn pé kí ó wá sèdá ayé àti àwon ènìyàn inú rè. Ìtàn náà so fún wa pé Odùduwà sòkalè sí Ilé-Ifè láti òrun pèlú àwon emèwà rè. Wón sì se isé tí Olódùmarè rán won ní àsepé. Nípasè ìtàn yìí, a lè so pé Ilé-Ifè ní àwon Yorùbá ti sè, àti pàápàá gbogbo ènìyàn àgbáyé.
Ìtàn mìíràn tí a tún gbó so fún wa pé àwon Yorùbá wá Ilé-Ifè láti ilè Mékà lábé àkóso Odùduwà nígbà tí ìjà kan bé sílè ní ilè Arébíà léyìn tí èsìn Islam dé sáàrin àwon ènìyàn agbègbè náà. Àwon onímò kan nípa ìtàn ti ye ìtàn yìí wò fínnífínní, wón sì gbà wí pé bí ó tilè jé pé ó se é se kí àwon Yorùbá ní ìbásepò pèlú àwon ará Mékà àti agbègbè Arébíà mìíràn kí wón tó sí kúrò, ibi tí wón ti sè wá gan-an ni íjíbítì tàbí Núbíà. Àwon onímò yìí náà gbà pé Odùduwà ni ó jé olórí fún àwon ènìyàn yìí.
Kókó pàtàkì kan tí a rí dìmú ni pé Odùduwà ni olùdarí àwon ènìyàn tí ó wá láti tèdó sí Ilé-Ìfè gégé bí ìtàn méjéèjì tí a gbó se so. Tí a bá ye ìtàn méjéèjì wò, a ó rí i pé kò se é se kí Odùduwà méjèèjì jé enìkan náà nítorí pé àsìkò tàbí odún tí ó wà láàrin ìsèdá ayé àti àsìkò tí èsìn Islam dé jìnna púpò sí ara won. Nítorí ìdí èyí a lè gbà pé nínú ìtàn kejì ni Odùduwà ti kópa. Ìdí mìíràn tí a fi lè fara mó ìtàn kèjì ni pé léyìn àyèwò sí ìtàn ìsèdálè Yorùbá fínnífínní, ó hàn gbangba pé Odùduwà bá àwon èdá Olórun kan ní Ilé-Ifè nígbà tí ó dé ibè. Àwon ìtàn kan dárúko Àgbonmìrègún tí Odùduwà bá ní Ilé-Ifè. Èyí fihàn pé kìí se òfìfò ní ó ba Ilé-Ifè, bí kò se pé àwon kan wà níbè pèlú Àgbonmìrègún. Èyí sì tóka sí i pé a ti sèdá àwon ènìyàn kí òrò Odùduwà tó je yo, nítorí náà, kò lè jé Odùduwà yìí ni Olódùmarè rán wá láti sèdá ayé gégé bí a ti gbó o nínú ìtàn ìsèdá.
Lónà mìíràn èwè, a rí èrí nínú ìtàn pé Odùduwà níláti gbé ìjà ko àwon òwó ènìyàn kan tí ó bá ní Ilé-Ifè láti gba ilè, àti pàápáà láti jé olórí níbè. Ìtàn Móremí àjàsorò tí ó fi ètàn àti èmí omo rè okùnrin kan soso tí ó bí gba àwon ènìyàn rè sílè lówó ìmúnisìn àwon èyà Ùgbò lè jè èrí tí ó fìdí rè múlè pé Odùduwà àti àwon ènìyàn rè ja òpòlopò ogun kí wón tó le gba àkóso ilè náà lówó àwon òwó ènìyàn kan tí wón bá ní Ilé-Ifè gégé bí ìtàn