Riran Alaini Lowo
From Wikipedia
Ríran Aláìní Lówó
Ojo (1982;19) se àlàyé àwon ìwà tí enikéni tí a bá pè ní omolúwàbí ní àwùjo Yorùbá ye kí ó máa hù. Fún àpeere
Omolúwàbí a máa gba òrò
aládùúgbò àti ojúlùmò ati
àwon elòmíràn béèbéè yéwò
bí elòmíràn bá wà ní ìsòro, omolúwàbí
yío gbìyànjú láti mú ìsòro rè kúrò
tàbí dín in kù.
Gbogbo wa ni a mò pé ìka kò dógba. Olódùmarè tí ó dá íka àwa ènìyàn ni ó dá àwa èdá inú ayé. Kò sí èrí pé àsìkò kan wà ní òde ayé yìí tí gbogbo èdá wà ní orísìí ipò kan náà. Nítorí náà, ó di dandan pé bí a ó se rí eni tí kò ní ànító ni a ó tún rí eni tí ó ní ànísékùn. Tí irú eni tí ó ní ànísékù yìí bá jé omolúwàbí ènìyàn, ó ye kí ó máa se ìrànlówó fún àwon eni tí ó kù díè káà tó fún.
Ìrànlówó kò pin sí ibì kan, kì í se lórí òrò owó nìkan. Orísìírísìí ònà ni a lè gbà ran aláìní lówó. Bí a rí eni tí ebi ń pa onítòhun se aláìní oúnje nìyen, tí a bá ní oúnje a lé fi ran irú eni béè lówó. Orlando sòrò lórí rirán aláìní lowo:
Torí òpò ènìyàn la se dá e lólá o
Torí tálíkà la se bùkún e e e
Má folá ló maláìní lójú
Orlando kò fèpo boyò rárá nínú àyolò òkè yìí. Ó rán wa létí pé Olórun ni ó ń dá ènìyàn lólá àtipé nítorí ríran tálíkà lówó ni. Orlando tún sòrò síwájú lórí ríran aláìní lówó:
Lílé: Àwon tí ò réran pa
Ló ye ko jeran ‘léyá
Ègbè: E tétí ke gbó mi
Mùsùlùmí òdodo
Lílé: Eran iléyà te rí yen
Tomo aláìní gbogbo ni
Ègbè: E tétí ke gbó mi
Mùsùlùmí òdodo
Nínú orin òkè yìí, Orlando bá àwon omo Yorùbá tí wón jé mùsùlùmí sòrò. Odún pàtàkì kan ni odún iléyá je ní àwùjo Yorùbá òde òní. Ní àsìkò odún yìí àwon mùsùlùmí tí wón bá ti wo iléyá a máa pa àgbò. Àwon olówó tí wón je òré olódún àti àwon aládùúgbò ni wón máa ń je oúnje àti eran odún wònyí. Ohun ti Orlando ń so nínú orin òkè yìí ni pé, àwon ènìyàn tí kò rí eran pa àti àwon aláìní ló ye kí ó je eran iléyá. Ó so ìtàn bí òrò se je béè ni inú èsìn àwon musulumi.
Bí ó tilè je pé òrò gidi ni Orlando so sílè yìí. Ó tó ojó méta tí ó ti ko orin òhún, a sì rí àwon tí ó nira fún láti yònda eran iléyà fún àwon aláìní. Ìmòràn tiwa ni pé, ó yé kí àwon mùsùlùmí tèlé ìtókasí Orlando yìí nítorí pé òpò aláìní wà tí won kì í fi eran jeun. Ànfààní ńlá ni eléyìí yóò jé fún won.
Bákan náà ni omo ń sorí ní àwùjo Hausa. Ìpò pàtàkì ni òrò ìrànlówó wà. Àlùkùránì tenu mó òrò kí á máa ran aláìnì lówó púpò. Nínú Sura ketàdínlógún (Al-Isra) ese kerìndínlógbòn, ikejìdínlógbòn, àti èkerìnlélógbòn. òrò wáyé lórí ríran aláìnì lówó, esè kerìndínlógbòn ní kí á ran àwon aláìní àti àwon arìnrìnàjò lówó, èsè kejìdínlógbòn sàlàyè pé fún ìdí pàtàkì kan, tí a kò bá lè fún àwon aláìní. Ó ye kí á fi sùúrù so fún won, kí á sì sòrò tútù fún won. Ese kerìnlélógbòn so pé kí á gbìyànjú láti ran omo òrukàn lówó, kí á sì má pa kún ísòro rè.
Nínú Àdíìtì ti Al – Bayhagi tí Ibn Abbas jé orísun rè kókó òrò ibè ni pé enikéni tí ó bá je àjeyó nígbà tí ebi ń pa àwon aládùúgbò rè kì í se mùsùlùmí òdodo. Nínú ìtúpalè Àdíìtì yìí ti Lemu (1993:64) se, ó ní òrò oúnjé fífi se sàárà àti bíbó aládùúgbò eni jé kókó pàtàkì tí Àlùkùránì àti àwón Àdíìtì tenu mó púpò. Ó ní enikéni tí ó bá ta ko ìmòràn Àlúkùráni yìí gbódò jé èdá tí ó mo ti ara rè nìkan.
Dan Maraya sòrò lórí ríran omonìkejì lówó. Bí àpeere
In muddin kana da shi ne
Kai taimako ga kowa
Ka taimakawa ga kowa
Ka aga zawa kowa
Ran komuwa ga Allah
Wallahi ka ji dadi
(Níwòn ìgbà tí o bá ní orò
Tí èrò re sí jé rere síse
O ran gbogbo énìyàn lówó.
O se àánú fún gbogbo èníyàn
Ní ojó ìpapòdà re
Dandan ni kí inú re kí ó dùn)
Nínú àyolò orin òkè yìí, Dan Maraya sàlàyé pé eni tí ó bá ní orò, tí ó ní èrò rere, tí ó sì ń ran àwon ènìyàn lówó pèlú eyinjú àánú Olórun yónú sírú eni béè àtipé inú dídun ni yóò fi papòdà. Àlàyé rè yìí wolé dáradára ní àwùjo Hausa. Lára nnkan pàtàkì tí omolúwàbí gbódò máa hù níwà ni àánú síse àti ìrànlówó fún aláìní yàtò sí pé irú ènìyàn béè yóò rí ìyónú Olórun, ìgbàgbó àwùjo Hausa ni pé irú èdá béè yóò ri ìyónú ènìyàn pàápàá.
Òkorin yìí tún sòrò síwájú síi lórí ríran aláìní lówó. Fún àpeere;
Taron jama ‘ar Allah,
In Allah ya ba ka,
In ya sa ka samu,
Ka aikate alheri,
Kamar Haladu farin tsoho
(Gbogbo mùtúmùwà
Ti Olórun bá fún yin ní olá
Máa se rere fún aráyé
Kí e sì mo iyì ènìyàn
Bí i Haladu Farin Tsoho)
Nínú àyolò òkè yìí, Dan Maraya ro gbogbo èdá tí Olórun bá fún ní olá pé kí wón máa se rere fún aráyé. Ìrànlówó síse fún aláìní jé òkan pàtàkì nínú ohun tí a fi ń se òdiwòn ìwà omolúwàbí ní àwùjo Hausa kò se é se kí ènìyàn sánjú kí á sì tún kà á sí omolúwàbí ní àwùjo Hausa.
Nínú ìtókasí Orlando àti Dan Maraya lóri ríran aláìní lówó bí ó se hàn nínú orin àwon òkorin mèjèèjì. Ò hàn pé àwùjo méjéèjì gbà pé wàhálà ni t’àgbè, Olórun ní pé kí isu ó ta. Olórun ní fún èdá ni olá. Àwùjo méjéèjì gbà pé nítorí kí èdá lè ran àwon aláìní lówó ni Olórun se n fun àwon olólá ni olá. Paríparí ni pé ara àwon ònà pàtàkì tí a lè fi dá omolúwàbí mò ni ríran aláìní lówó nínú àwùjo Yorùbá àti Hausa. Kò sí ìyàtó nínú ìgbàgbó àwùjo méjéèjì lórí òrò ríran aláìní lówó. Ohun tó ń sèlè ní àwùjo ni òkorin méjééjì ń so fáráyé gbó