Agbalagba Akan
From Wikipedia
Agbalagba Akan
Okediji
Oládèjo Òkédìjì (1971), Àgbàlagbà Akàn. Ìkeja, Nigerai: Longman Nigeria Ltd. ISBN 978-139-095-6.
Ìpànpá awón ogboju olosa kan nse bí nwon ti fe, lati Ibadan titi de Origbo, apá awon olopa ko si ká won. Lapade wá gbà a kanri lati se àwárí ibùba awon ìgárá ole yi, ki oun si kó won le ijoba lowo. Enia meta òtòtò ni iku òjijì pa ní ojo ti ìwadi naa bèrè, oniruuru àjálù miran sit un nyoju ní sísèntèlé; sugbon kàkà kí Lapade já nkan wonyi kúnra, ó worímó iwadi naa ni. Awon olopa kò dunnú si atojúbò tí Lapade nse si ise won, nitorinaa nwon hàn án ni kugú èmmò. Awon olosa si ńsa gbogbo ipá won lati sí i lowo. Sàsà enia ni yio le pa ìwé yi dé lai tii kà ìtàn inu rè tán.
ÀGBÀLAGBÀ AKÀNni ekeji ninu awon ìtàn òtelèmúyé kan ti nje Lapade. Oruko ìtàn kínní ni ÀJÀ L’Ó L’ERÙ. Òwe àtàtà, ijinle oro, àgbà òrò, àwàdà, ati ídaraya orisirisi ni ó dá awon ìtàn Lapade lówó awon ti o kundun Yorùbá kíkà. Ogunlogo ònkàwé l’ó ńkan sáárá si Oladejo Okekdiji fun dídá irú itan yi sile ní ede Yorùbá, ati fun bírà gbogbo ti o nfi ede naa dá.