Ebo Riru

From Wikipedia

EBO RÍRÚ

A lè kí ebo rírú gégé bí ìgbìyànjú èdá láti mú nínú nnkan ìní rè bi: owó, aso, oúnje, epo, eja, eran àti ògòòrò irúfé àwon nnkan mèremère mìíràn tí ó wà ní ìkáwó èdá fi tore fún aládùúgbò rè tàbí eranko àti òkànlénírinwó àwon èmí àìrí wòn-on-nì tí a gbàgbó pé wón lágbára láti tún ayé eni se tàbí láti mú kí olúwarè ó ma rí bátisé e. kì í se àwon tí kì í se onígbàgbó tàbí Mùsùlùmí nìkan ló máa ń rú ebo. Gbogbo èsin ni ebo rírú je lógún, tí ó sì múmú láyà won bí omo túntún.

Ebo rírú kò yo enìkankan sílè rárá. Ibi gbogbo ni à ń kó adire alé ni òrò ebo jé fún èsìn àbáláyé, èsìn kiriyó àti èsìn Mùsùlùmí. Orúko àti ònà tí èsìn kòòkan ń gbà láti rú ebo tirè ló lè yàtò sí ara won. Eni tí ó rúbo ni Èsù ú gbé. Rírú ebo ní í gbeni, àìrú rè kì í gbe ènìyàn. Fún àpeere, àwon alàwòrò tàbí omoléyìn Mòhámédù máa ń se sàráà ni gbogbo ojó Jímò. Wón á dín mósà lo sí akòdì ìjósìn won fún Jànmó-òn láti je. Bákan náà ní àmòlà kì í gbéyìn rárá. Bí Mùsùlùmí bá kó kéwú dé oríkèé kan, won a omo èkósé kéwú ó se sàráà; èyí tí won ń dàápè ní “Wòlímò” omo kéwú yìí lè pa adìe tàbí eranm àgbò. Bí ó bá tún kéwú náà síwájú sààà tàbí tí ó tán kùránì, wón a pa màlúù. Ebo rírú ni gbogbo ìnáwó wònyí.

Bí ó bá tún di àkókò odún iléyá àti odún ìtúnu ààwè, àwon omoléyìn Ànábì Mòhámédù a tún pa eran, won a ta èjè sílè. Won yóò há eran yìí fún àwon aládùúgbò won bí ó ti to àti bíu ó ti ye. Ìyá-Súnà, gbà, eran odún re nìyí. Ìyá-Káà, gbà o, tìe nìyí. Tí ìyá Súnà àti ìyá Káà bá gba eran odún tán, won a ní enu òbe kò ní í sélè o, àse. Ebo rírú kan kò ju èyí lo. Onígbàgbó tàbí àwon àwòrò Jésù náà ní àkókò odún Kérésìmesì, odún ajínde tí won fi ń kóta ikú Jésù àti àjòdún ìkórè ní òpin odún. Wón máa ń peran tí won ó sì wá oúnje pèlú nnkan yòówù tí wón bá tún nípá láti mú wá sí iwájú pepe. Won a ní àwon ń dáná odún, e n só nílé bàbà ìjo kí á lo jó tàbí je oúnje odún. Sàká tàbí ìdáméwàá yíyo nínú nnkan yówù tí èdá ba ni láti fi dúpé tàbí tore pín lára àbùdá ebo rírú bakan náà.

Gégé bí Gíwá Ifáfitì Ifè, Olóyè, Òjògbón Wándé Abínbólá tí so: ebo Yorùbá kì í se ebo tí a rú láti dá ènìyàn nídè kúrò nínú ìgbèkùn èsè rè. Sùgbón èyí kì í se ti òrò èsìn Kiriyó àti èsìn Mùsùlùmú. Tí Mùsùlùmí bá sèsè ba ìyàwó won lò pò tán, wón níláti we Jínníbà kí won ó tó lo sí akòdi ìsìn won. Àwon ìgbàgbó ìjo Mímó láti òrun wá (Celestial Church of Christ) àti ìjo Kérúbù àti Séráfù náà máa ń we irú ìwè yìí; won a ní a kò gbodò gbé ara àìmó wo ilé ìjósìn.

Síwájú sí i, àwon ìjo Aládùúrà àti ìjo Àpóítélì lè wí pé kí alàwòrò won lo wè ní odò tó ń sàn tàbí kí won lo fi iye àbélà kan gbàdúrà kí olúwarè lè rí ìdándè tàbí ìségun gbà. Ebo rírú ní gbogbo nnkan wònyìí. Òrìsà tàbí àwon ìbo mìíràn bíi Sàngó, Ògún, Òrúnmìlà abbl. ni oroorún, tí a sì ń yánlè oúnje fún òkú-òrun pèlú nígbà gbogbo tí a bá ń jeun. Bákan náà ni Yorùbá tún máa ń pa èyìn arúgbó won dà tó tí papòdà ni ìbámu pèlú ìgbàgbó nínú àjínde òkú pé ikú kì í se òpin èdá ni ayé.

Òrìsà kòòkan ló ní oúnje tirè tí ó féràn láti máa je. Nnken tí ara Eégún gbà, ara Orò lè kò ó. Èyí wù mí kò wù ó ni kò jé kí omo ìyá méjì pa owó pò fébìnrin. Fún àpeere. Okà tàbí Àmàlà, gbègìrì àti eran àgbò ni Sàngó, Olúkòso Arèkújayé Onílagbàjìnnìjìnnì féràn; Ògún Onírè féràn emu àti eran ajá; Eégún a sì máa gba èkuru, otí pèlú obì. Òrúnmìlà a máa gba:

Eku méjì Olùwéré,

Eja méjì abiwègbàdà;

Ewúré méjì abàmú rédérédé;

Einlá méjì tó fiwo sòsùká;

Eye méjì abìfò gàngà.

Ata tí ó síjú,

Obì tí ó làdò,

Otí àbodà.

Ní ònà kejì, ebo rírú wà fún ìtooro ààbò àwon ìbo àti òkú-òrun lórí odidi ìlú tàbí eníkòòkan wa. Ebo ni òjá tó so wá pò mó àwon Irunmole wònyìí. Nípa ebo rírú ni a lè fi ségun àwon ajogun. Bí a bá ti rúbo tán, dandan ni kí àwon Ajogun (Òràn, Èpè, Òfò Àrùn, Èse, Ikú, Egbà àti Èwòn) ó padà léyìn eni tí won ń se. Eni tí ó bá rúbo ni Èsù ú gbè. Ìdí nìyí tí Ifá Olókun, Asòròdayò fi so wí pé:


Onídúdú gba dúdú

Onípupa gba pupa,

Aláyìnrín gbàyìnrín.

Báràápetu, ò bá mò mò kókú o kárùn,

Báràápetu.

Ní ònà keta, ebo rírú máa ń ran ìpín tí enìkòòkan wa yàn láti òrun lówó láti má jèé kí í fi orí sánpón. Bákan náà ló tún ń jé kí aburú tó wà nínú ìpín wa ó féri. Ebo rírú yìí ní ó máa ń fa aso òfò wa ya. Bí ó ti wù kí oòrùn ó mú tó, sánmò dúdú díè yóò wà, bí ó ti wù kí ayé wa láyò, yóò ní àkókò ekún rè. Rírú ebo yìí ló máa ń dín àkókò ekún kù nínú ìgbésí ayé omo èdá. Rírú ebo ní í gbeni, àìrúi rè kì í gbe ènìyàn. Ese wúrà kan láti inú ìwé mímó àwon Yorùbá. Ifá tilè fi yé wa pé ìpààro ara eni ní ebo-rírú jé. Nígbà tí àwo a jogun bá dé, tí won sì gbógun tin i, bí a bá fi nnkan ìní bí owó, aso, eja, eran, epo tàbí nnkan mìíràn kébo rú, tí Esù bá sì ti gba ebo náà tí ó gbé e fún àwon ajogun, dandan ni kí won ó pèyìndè, kí won ó si lo. Esù Ifá náà lo báyìí:

………………………………………….

Pààrò pààrò, awo ilé Elépè,

Àrùn wáá fElépèé í lè,

Orí eran ló mú lo.

Pààrò paaro, awo ilé Elépèé

Òfò wáá fElépèé í lè,

Orí eran ló mú lo.

Pààrò paaro, awo ilé Elépèé,

Ajogun gbogbo wáá fElépèé í lè,

Orí eran ló mú lo,

Pààrò paarò, awo ilé Elépè.

Ní ònà kerin, ebo jé oúnje pàtàkì fún àwon babaláwo pàápàá. Irú nnkan báyìí tí babaláwo máa ń rí mú sílè lára ebo ni Yorùbá ń pè ní èrù. Níwòn ìgbà tí ó jé wí pé babaláwo tó jé oníwòsàn àti onísègùn ìsèse ní ilè Káàárò-Oòjííire kì í gba owó òya èrù yií ni wón ń je. Ìdí nip é eni tó bá se ni ibi pepe ní í je níbi pepe. Sùgbón ohùn kan tí ó jé dandan ní owó orí òràn-an-yàn ni aso ìbora nip é Òrúnmìlà gbódò fún awo ní àse láti mú nínú nnkan tí oníbèérè fi rúbo kí ó tó dip é wón lè mú níbè kànńpá ni èyí. Ìdí nip é ki í se gbogbo ìgbà ni àwòrò Ifá ní ànfààní láti mú nínu nnkan tí a fi rúbo. Bákan náà ni àwon awo gbódò kókó yo tí àwon ajogun àti ti Esù pèlú àwon ìbo gbogbo sótò kí won ó tó mú tiwon nínú ebo náà. Ifé ní ti Opón bá téjú tán, Awo lè je:

Òtítí baba ajé

Ológìnìnginnì Aso Ràdà àti

Àkónkótán ohun òrò nIfè.

Ní àfikún, ebo jé ìpèsè oúnje fún enu omo aráyé. Ènìyàn kì í je ògèdè kó wú ni léèkà eru omo aráyé lebo. Ebo rírú kò wà fún àwon ìbo enu aráyé náà kí á máa baà rí ìjà won. Enu tótó fun – ùn. Enu tó so igbá di ògbún tó tún so ògbún di ìgbako. Ìgbàgbó Yorùbá ni pé tí enu bá je tán, ojú yóò tì. Àwon omo aráyé yóò sì súre fún eni tí ó rúbo. Ifá Olókun Asòròdayò ní:

………………………………….

N jé kín là ń bo nÍfè?

Enuu won.

Enuu won là ń bo nÍfè,

Enuu won

Mo fúngbá,

Mo fáwo.

Enuu won,

Enuu won kò mà lè rí mi bá jà.

Enu won.

Mo wálé,

Mo wánà.

Enuj won,

Enuu won kò mà lè rí mi bá jà.

Enuu won.

Síwájú sí i, ebo rírú tún se pàtàkì nítorí pé ó jé oúnje fún àwon eranko bíi ajá àti eye ojú òrun bìí igún. Eranko bíi ajá àti eye igún féràn ebo jíje. Ìdí nìyí tí a fi máa ń so pé

Nnken ti ajá ó je Èsù ó wá a.”

Ese Ifá kan tún se àlàyé síwájú lórú òkodoro òrò yìí láti fi òtító múlè wí pé bí a kò bá rí gúnnugún, a kò le è se ebo, bá ò rákàlàmàgbò, a ò sorò. Ese Ifá náà lo báyìí:

Sàlàgbèrèjè ló dífá fún gúnnugún,

Omo olójògbòòlórò.

Sàlàgèrèjè wáá jebo…

À sé bá ò rí gúnnugún,

A kì yóó lè sebo.

Bá ò rákàlà,

Sàlàgbèrèjè wáá jebo.

Igún wáá jebo,

Kébo ó lè baà fín.

Ètìé wáá jebo,

Kébo ó lè baà dà

Igún, ètìé, aráà Lódè.

Sàlàgèrèjè wáá jebo.

Oògùn wà ní lílò ní ìgbà tí ojó bá pedí. Sùgbón nígbà mìíràn ewé lè sunko. Ebo kì í bà á ti. Ìdí nìyí tí àwon Yorùbá kì í fi sahun ebo rírú. Osanyin ni baba ìsègùn; Ifá Olókun Asòròdayò, Akéréfinúsogbó, Akónilóràn-bí-ìyekan-eni, okùnrin kúkúrú òkè ìgélì, Alóhun-orò-jegbé-ro-lo ló ni ebo. Ìdí nìyí tí Yorùbá fi máa ń wí pé:

Sarí má saàgun.

Oògùn ló ni ojó kan ìpónjú

Ebo àti orí ló ni ojó gbogbo.

Rirú rè kì í gbe ènìyàn.

Ní ìkádìí, bí a bá ti gbó rírú ebo tí a rú, tí a gbó itú àtùkèsù tí a tù, tí a sì tún gbó òkarara ebo tí a há a fún àwon ìbo, òkú-òrun, ènìyàn àti eraniko igbé tán, nnkan tí ó kù ni kí òfò, òràn, epè, àrùn, ikú, èse, èwòn àti ègbà ó máa gbé igbé wo wá kí towó-tomo ó wolé wá bá wa. Ire nínú ni ìgbèyìn eni tí ó yan orí rere, tí ó fi apá àti esè se akitiyan tí ó gbámúsé, tí ó sì fí àyà yan òré tí ó ní láárí, tí ó sì tún rú ebo. Èyí náà ló dífá fún ògòòro ese Ifá tó máa ń parí pèlú ire. Fún àpeere

(i) Rírú ebo,

Àtètè tù èrù,

E wáá bá ni ní jèbutu ire.


(ii) Ilé nìyí òun aya ò,

Ilé nìyí òun omo

Èèyàn èé se fíyà láìnílé.

Ilé nìyí òun omo.


(iii) Ire méta làwá ń wá,

Àwá ń wówó o,

Àwá ń wómo,

Àwá ń wá àtubòtán ayé.


Eni tí ó bá pe awo lékèé, tí ó pe Èsù lólè, tí ó wo òrùn yànyàn bí eni tí kò ní í kú mó, tó ko etí ògbon-in sébo, ó di dandan kí àwon ajogun pa àgó tí olúwarè. Ìdí nip é bí a bá seni lóore tí kò dúpé bí olósà kó ni lérù lo ni. Bí a bá sì se é ni ibi náà kò láìfí. Ònà láti fi èmí ìmoore hàn, kí á sì tún tooro ààbò àti ojú rere àwon èdá tí a rí àti èyí tí a kò rí ni ó bí ebo rírú.

àjosepò òkú òrun àti ará ayé ìpàdé - àpèje

Ki o le gbé òràn fò ni

Kì í se fún ìdáríjì èsè tí

a ti se bí i tí àwon omo

léhìn Jéésù.



Báre Atóyèbí

ÌTÓKA

E.B. Ìdòwú: Olódùmarè: God in Yoruba Belief

Wándé Abimbola: Ifá: An Exposition of Ifá Literary Corpus.

Ìjìnlè Ohùn Enu Ifá, Apá Kínní

Ìjìnlè Ohùn Enu Ifá, Apá Kejì

Àwon Ojú Odù Mérèèrìndínlógún