Akoole Yoruba I
From Wikipedia
Akosile Yoruba
ÌTÀN ÀKOÓLÈ YORÙBÁ:
Ònà méjì ni a ó gbà fi wò èyí - Ònà kìíní ni ‘Ìtàn Yorùbá’. Ònà kejì sì ni ‘Àkoólè Yorùbá’. Òpòlopò Ìtàn ni ó ti wáyé lórí ibi tí Yorùbá sè wá. Iròyìn yìí yàtò sí ara won sùgbón gbogbo won gbàwí pé ń se ni Yorùbá sí láti àríwá ìlà-oòrùn wá sí ibi tí wón tèdó sí nísisìyí. Dr. Johnson so wí pé ilè ijibiti ni Yorùbá ti sè wá. Ó fi Nimrod oba Ijibiti tó rin ìrìn-àjò omo ogun lo sí ilè Arabia láti fi se ibùgbé sùgbón tí wón lée nítorí ìjà esin. Dr Luca fara mó èrò Johnson nípa títóka sí àwon èdè Yorùbá àti ti Ijibiti tí ó papò tàbí jora. AKIYESI:
Dr. Biobaku àti àwon egbé rè tako èrò. Dr. Lucas lórí èdè Yorùbá àti ti Ijibiti tí ó jora. Ó ní só seé se kí èdè papò nípa òwò. Ó ní à ti pé Dr. Lucas ti pón èrò rè ju bí ó ti ye lo. Dr Idowu fi èrò tirè hàn pé Olódùmarè ló rán odùduwà wá ní àsìkò ti gbogbo ayé kún fún omi. Odùduwà da iyanrìn tí olódùmarè fun láti òrun sí orí omi, eyelé wá tàn-án yíká, odùduwà àti ènìyàn mérìndínlógún wá sòkalè sí Ilé-Ifè tí ó jé orírun Yorùbá. Nígbà tí ó yá àwon Ìgbò bèrè sí fi ara hàn wón gégé bí iwin/òrò nípa dída imò òpe bora láti máa yo wón. lénu. Léyìn ìwádìí lódò òrìsà, Moremi (arewà obìnrin) yònda láti bá àwon Ìgbò lo sí ìlú won. Èyí mú kí ó ri àsírí àwon Ìgbò, ó wá padà wá láti tú àsírí náà fún àwon ènìyàn rè. Ó wá mú omo rè kan soso “Olúorogbo” láti fi rúbo sí àwon òrìsa fún èjé tí ó jé. Èrò àwon tí ó se àtúnpalè Bíbélì láti èdè Oyìnbó sí èdè Yorùbá ní nnkan bíi èéégbèwá odún (19th century) ni pé ‘àsà’àti èrò inú àwon Heberu kò yàtò sí ti àwon Yorùbá Nínú òpòlopò ìròhìn, a lè pinnu láìsiyèméjì pé àwon Yorùbá láti ibi kan wá sí Ilé-Ifè ni. Bíi èédégbèrin odún sí èédégbèfà odún ni a gbà wí pé ó jé àsìkò tí Yorùbá sí láti ibìkan wá sí Ilé-Ifè. Dr. Biobaku, léyìn òpòlopò ìwádìí rè gbà wí pé nípa àtìleyìn àwon omo Ijibiti, Heberu àti àwon kan ni odùduwà àti àwon ènìyàn rè fi dé ibi tí wón fi se àtìpó ní nnkan bíi èédégbèrin odún pèlú àkójopò òtòòtò. Adémólá Fasiku fara mó èrò Dr. Johnson sùgbón Professor J.A. Atanda tako èrò yìí, ó ní apá ìwò oòrùn ni odùduwà àti àwon ènìyàn rè ti wá. Bákan náà wón ní ìjà èsìn tó mú kí Odùduwa ní kí wón pa omo rè Bùráímò elésìn Mùsùlùmí ni ó múu sá kúrò ní ìlà oòrùn láti wá tèdó sí Ilé-Ifè níbi tí ó ti bá Àgbonmiregun (sètílù-onífá) pàdé. Lára nnkan tí wón kó dé Ilé-Ifè ni ère méjì àti àlùkùránì fún bíbo. Àwon kan so pé Òkànbí nìkan ni Odùduwà bí, àwon kan ni béè kó pé omo mérìndínlógún ni, àwon kan tún so pé méje ni. Ìtàn tí ó wá so pé Òkànbí ni ó bí omo púpò, pé méje sì ni, ni enu kò lé lórí jùlo - Olówu, Alákétu, Oba biini, Òràngún Ilé-Ìlá, Onisabe ile sabe, Olúpópó oba pópó, Oranyan ti Òyó Ilé. Ju gbogbo rè lo bí èyà kan se se àti bí wón se bá ìrìnkèrindò won dé ibi tí wón wà lónìí kò yé enikéni. Ìgbàgbó wa ni pé omo odùduwà ni gbogbo wa àti pé Ilé-Ifè ni ati sè wá. Ìsesí, Ìhùwàsí, àsà àti èsìn wa kò yàtò. Lónà kejì, àwon onímò Lìngúísíìkì se àkoólè Yorùbá Bowdich ati Clapperton lo kókó gbìyànjú kíko òrò Yorùbá sílè. Akitiyan àkókó láti gbé ìlànà àkotó Yorùbá kalè wáyé láti owó J.B. Raban (1830-1832). Akitiyan yìí ran Ajayi Crowther, Gollmer, M.D’Avezac lówó láti se àtúpalè èdè Yorùbá. Eléyìí mú kí ìjo. C.M.S. níbi tí Raban ti jé ajíhìnrere pàsè lílo èdè Yorùbá nínú ìsìn ní 1844. Ní 1824 – 1830 Hannah kilham se ìbèwò sí ìwò oòrùn Áfíríkà léèméta lórí kíko àkoto tó rorùn, tó sì já gaara. Ní 1875 asojú gbogbo ìjo pe ara won jo láti fi enu kò lórí ònà kan soso tí won yóò máa gbà ko Yorùbá sílè. Lára àwon kókó náà nìwònyí:
(i) Lábé, o, s, ìlà kékeré ni kí á fà, kì í se kíkánmo sí nídìí
(ii) ‘gb’ kìí se ‘bh’ tabi ‘b’
(iii) P (kì í se ‘kp’)
(iv) Àtòsílè àwon òrò tí wón ní édà èka-èdè, U tàbí O nínú ìró àrańmúpè. O dúró nínú àbàwón; U nínú àdánù.
(v) Òfin lílo àmì-ohùn
ÀKOSÍLÈ TI O N SO NÍPA ORIRUN YORÙBÁ
Aáyan àwon onísé ìwádìí láti topinpin àwon Yorùbá ló gbé wa lo sínú àkosílè tí ó kókó ménu bà èyà Yorùbá. Irú àkosílè béè ni a gbó pé ‘Sultan Bello’ tíí se eni tó te ìlú sokoto dó, ko sílé ní èdè Hausa. Àkosílè yìí ni Captain Clapperton nínú isé Sultan Bello tí í pe àkolé rè ní “History of the Sudan”. Sultan Bello so báyìí nípa àwon Yorùbá, pé àwon èyà tí ń gbé ní agbègbè (Yarba) jé àrómódómo omo kénáànì, tí í se èyà “Nimrodu” ó tè síwájú láti so fún wa pé ohun tí ó sín won dé ìwò oòrùn Afirika ni lílé ti Yaarooba tí í se omo Khanta lé won kúrò ní ilè Arabia sí ààrìn ìwò oòrùn láàrin ilè ifibiti si Abyssiana, àti agbègbè ibè wón tí wo ààringbùngbùn ilè Afirika wa tótí won fi i tèdó sí ibi tí won fi se ibùdó báyìí tí a mò sí ilè Yarubá èyí ní Yorùbá. Nínú ìrìn àjò won, won a fi èyà won sílè ni ibikíbi tí wón bat i dúró. Ìdí nìyen tí a fi gbà pé àwon èyà ‘Sudan tí ó ń gbé ni orí òkè orílè èdè jé èyà àwon omo Yorùbá. Ohun ti àkosílè yìí ń so ni pé ó se é se kí ó jé pé lára àwon èyà tí a mò sí Yorùbá lónìí ni ‘Sultan Bello’ ń tóka sí nínú àkosílè rè.