Bamiji Ojo
From Wikipedia
Bamiji Ojo
A.O. Adeoye (2000), ‘Ìtàn Ìgbésí Ayé Bámijí Òjó’, láti inú Àtúpelè Ìwé Oba Adìkúta tí Bámijí Òjó ko.’, Àpilèko fún Òyè Bíeè, DALL, OAU, Ifè Nigeria.
Itàn Ìgbésí Ayé Bámijí Òjó
A bí Bámijì Òjó ní egúnjó osù kewàá odún 1939 ní ìlú ìlóràá, ní ìjoba ìbílè Afijió ní ìpínlè Òjó. Orúko àwon òbí rè ni Jacob Òjó àti Abímbólá Àjoké Òjó. Isé àgbè ni àwon òbí rè ń se.
Ojú ti ń là díè nígbà náà, eni tí ó bá mú omo lo sí ilé-ìwé ní ìgbà náà, bí ìgbà tí ó fi omo sòfà tí ó mú omo lo fún òyìnbó ni. Sùgbón àwon òbí rè pa ìmò pò wón fi sí ilé-ìwé alákòóbèrè ti ìjo onítèbomi ti First Baptist Day School ìlú Ìloràá ni odún 1946. O se àseyerí nínú èkó oníwèé méfà, tí ó kà jáde ni ilé-ìwé alákòóbèrè. Nígbà náà wón ti ń dá ilé èkó gíga Módà (Modern School) sílè. Bámijí Òjó se ìdánwò bó sí ilé-ìwé Local Authority Modern School ní ìlú Fìdítì, ó wà ní ibè fún odún méta (1956-1959).
Léyìn èyí nínú odún 1960, Bámijí Òjó se isé díè láti fi kówó jo. Nítorí pé kò sí owó lówó àwon òbí rè láti tó o kojá ìwé méjo. Léyìn tí ó ti sisé tí ó sì kówó jo fún odún kan pèlú ìwé èrí “Modern School”, ó tún tíraka láti tèsíwájú lénu ìwé rè. Ó lo sí ilé-ìwé ti àwon olùkóni ti “Local Authority Teacher Training College” ní ìlú Òyó láti inú odún 1961 di odún 1962.
Ìgbà tí ó parí èkó rè ni ó bèrè isé tísà, bí ó tilè jé pé kì í se isé tí ó wù ú lókàn gan-an láti ilè pèpè ni isé tísà. Ó se isé tísà káàkiri àwon ìpínlè bí i Sakí, Edé, Ahá. Sùgbón isé ìròyìn ni ó múmú ní okàn rè.
Bámijí Òjó wà lára àwon méjìlá àkókó tí wón gbà ní odún 1969 láti kó Yorùbá ní Yunifásitì Èkó. Nígbà náà ojú òle ni wón fi máa ń wo eni tí ó bá lo kó Yorùbá ní Yunifásitì.
Léyìn tí ó parí èkó rè ni wón gba Bámijí Òjó sí ilé isé ìròyìn ní odún 1970, Àlhàájì Lateef Jákàńdè ni ó gbà á sí isé ìròyìn ní ilé-isé “Tribune”ní ìlú Èkó, gégé bí igbá kejì olóòtú Ìròyìn Yorùbá. Sùgbón nítorí pé ó tin í ìyàwó nílé nígbà náà wón gbé e padà sí Ìbàdàn. Ilé-isé won wà ní Adéòyó. Ní àsìkò yìí kan náà ni Bámijí Òjó ronú pé isé ìròyìn ti orí Rédíò Sáá ní ó wu òun. Ó wá ń bá won sisé aáyan ògbufò ni ilé-isé “Radio Nigeria”. Èyí ni ó ń se tí ó fi ń sisé nílé isé “Tribune” àti nílé isé “Radio Nigeria”.
Ní odún 1971 ni wón gba Bámijí Òjó gégé bí onísé Ìròyìn ní ilé isé “Radio Nigeria”. Àwon tí wón jìjo sisé ìròyìn nígbà náà ni Alàgbà Oláòlú Olúmìídé tí ó jé ògá rè, Olóògbé Àlhàájì Sàká Síkágbó àti Olóògbé Akíntúndé Ògúnsínà àti bàbá Omídèyí.
Nítorí ìtara okàn tí Bámijí Òjó ní láti sisé nílé isé Telifísàn ó kúrò ní “Radio Nigeria”, ó lo sí “Western Nigerian Broadcastint Service” àti “Western Nigerian Televeision Station” WNBS/WNTV tó wà ní Agodi Ìbàdàn, nínú osù kokànlá odún 1973. Ni ibè ni okà rè ti balè tí àyè sì ti gbà á láti lo èbùn rè láti gbé èdè, àsà àti lítírésò Yorùbá láruge. Ìràwò rè si bèrè sí í tàn gidigidi lénu isé ìròyìn. Nígbà ti Bámijí Òjó wà ní “Radio Nigeria” kí ó tó lo sí “Western Nigerian Television Station (WNTV)” ni wón ti kókó ran àwon onísé ibè lo sí ilé èkó láti lo kó èkó nípa bí wón se ń sisé nílé isé Rédíò. Ilé isé Rédíò ní Ìkòyí ni won ti gba idánilékòó yìí. Ìdí nip é tí ènìyàn bá máa sòrò nílé isé “Radio Nigeria”nígbà náà ó gbódò kó èkó. Lára àwon ètò tó máa ń se lórí èro Telifísàn ni “Káàárò-oò-jíire” àti “Tiwa-n-tiwa” túbòsún Oládàpò, Láoyè Bégúnjobí àti àwon mìíràn ni wón jo wà níbi isé nígbà náà. Gbogbo akitiyan yìí mú kí ìrírí Bámijí gbòòrò si nípa isé ìròyìn àti ìsèlè àwùjo pèlú àwon ènìyàn inú rè.
Ní odún 1976 ni Bámijí Òjó lo fún ìdáni lékòó ní Òkè Òkun, ní orílè èdè kenyà níbi tí ó ti gba ìwé èrí “Certificate Course In Mass Communication” (Ìlànà Ìgbétèkalè lórí aféfé).
Nígbà tí ó di osù kewàá odún 1976, ni wón dá àwon ìpínlè méta sílè, Òyó, Òndó àti Ògùn, Bámijí jé òkan lára àwon tí ó kúrò ni ilé isé “Western Nigerian Broadcasting Services” àti “Western Nigerian Television Station (WNBS/WNTV) tí ó lo dá Rédíò Òyó sílè. Engineer Olúwolé Dáre ni ó kó won lo nígbà náà, Kúnlé Adélékè, Adébáyò ni wón jìjo dá ilé isé Rédíò sí lè ni October 1976, wón kó ilé isé won lo sí Oríta Basòrun Ìbàdàn.
Nínú odún 1981 ni Bámijì Òjó tún pa isé tì, tí ó tún lo fún ètò ìdánilékòó lórí bí a se ń se isé Rédíò ní ilé isé Rédíò tí ó jé gbajúgbajà ní àgbáyé tí won ń pè ní “British Broadcasting Co-operation (BBC) London fún Certificate Course.
Ní odún 1983 ni ó lo sí orílè èdè Germany fún ìdánilékòó Olósù méta ní ilé isé Rédíò tí à ń pè ni “Voice of Germany”. Níbè ló ti kó èkó nípa isé Rédíò àti Móhùnmáwòrán. Ìgbà tí Bámijì Òjó dé ni ó jókòó ti isé tí ó yìn láàyò. Èyí ni ó ń se títí tí wón tún fi pín Òyó sí méjì tí àwon Òsun lo, èyí mú kí ànfààní wà láti tè síwájú. Orísìírísìí ìgbéga ni ó wáyé nígbà náà sùgbón ìgbéga tí ó gbèyìn nínú isé oníròyìn ni “Director of Programmes’ tí wón fún Bámijí Òjó nínú osù kesàn-án, odún 1991, Ó sì wà lénu isé náà gégé bí olùdarí àwon èka tí ó ń gbóhùn sáféfé títí di odún 1994. Ojó kokànlélógbòn osù kejìlá odún 1994 ni ó fèyìn tì.
Ní odún tí ó tèlé, nínú osù kìíní odún 1995 ni Bámijì Òjó dá ilé isé tirè náà sílè. Èyí tí ó pa orúko rè ní ‘Bámijí Òjó Communicatio Center’.
Bámijì Òjó tin í iyàwó béè ni Olórun sì ti fi omo márùn-ún dá a lólá.
Orísìírísìí èbùn móríyá àti ìkansáárásí ni Bámijí Òjó gbà nígbà tí ó wà lénu isé ijoba. Fún orí pí pé àti ìmò ìjìnlè rè tí ó fi hàn ní ilè Germany. Ó gba onírúurú èbùn fún àseyorí àti àseyege ní òpin èkó náà. Pèlú ìrírí àti èkó tó kó ní ‘London’ àti ‘Germany’ó di omo egbé tí a mò sí ‘Overseas Broadcasters’ Association’.
Ní odún 1990 ni ògágun Abudul Kareem Àdìsá fún Bámijí Òjó ní èbùn ìkansáárá sí, èyí ni ‘Òyó State Merit Award for the best producer or the year’. Fún ìmo rírì ètò tí ó ń se ní orí ‘Television Broadcasting Co-operation Òyó State (BCOS)’ Só Dáa Béè tí àwon ènìyàn ń jé ànfààní rè, Aláyélúwà Oba Emmanuel Adégbóyèga Adéyemo Òpérìndé 1. ni ó fi oyè Májèóbà jé ti ilú Ìbàdàn dá a lólá, nínú osù kokànlá odún 1994. 1.5 Bámijì Òjó Gégé Bi Ònkòwé Ìwé Ìtàn Àròso Yorùbá
Ìwé kíko je ohun ti Bámijì Òjó nífèé sí. Oba Adìkúta jé òken lára ìwé méjì sí méta tí ó ti ko jáde.
Ìwé àkókó tí Bámijì Òjó ko jáde ni Ménumó. Ìwé yìí jáde ni odún 1989.
Léyìn èyí ni Bámijì Òjó ko ìwé rè kejì. Oba Adìkúta tí ó jáde nínú osù keta odún 1995.
Nígbà tí Bámijì Òjó wà ní ilé isé “Radio Nigeria” ni ó ti kókó ko ìwé kan tí ó pè ní Àsà Àti Òrìsà Ilè Yorùbá. Ìwé yìí wà lódò àwon atèwétà tí ó gbàgbé sí won lódò tí kò sì jáde di òní olónìí.
Bámijì Òjó gégé bí enìkan tí ó ní ìtara okàn. ó tún ní àwon ìwé méjì tí ó wà lódò rè tí yóò jáde ní àìpé. Àkókó ni Sódaa Béè. Ìwé yìí jé àbájáde ètò kan tí ó se pàtàkì lórí Rédíò.
Òmíràn ni ètò Èyí Àrà. Bámijí Òjó ni ó dá ètò náà sílè¸ní ojó kìíní osù kerin odún 1984. Ní ilè Yorùbá pàápàá jù lo “South West”, òun ni ó bèrè rè, kò sí ilé isé Rédíò tí ó síwájú rè bèrè ètò yìí “Phone In” Èyí Àrà.