Agemo

From Wikipedia

C.O. Onanuga

C.O. Onanuga (1981), ‘Agemo’ láti inú ‘Odún Òrìsà Agemo ní Agbègbè Ìjèbú-Òde.’, Àpilèko fún Oyè Bíeè , DALL, OAU, Ifè, Nigeria, ojú-ìwé 17-20.

Agemo

ÌPÒ ÒRÌSÀ AGEMO LÁÁÀRÍN ÀWON ÌJÈBÚ.

Agemo ni àwon Ìjèbú gbà sí àgbà fún gbogbo òrìsà yòówù ní ilè Ìjèbú. Enì kan, tàbí àgbáríjo pò àwon díè lè se odún Ògún tàbí tí Ifá fúnra won. Sùgbón èyí kò rí béè fún odún Agemo. Gbogbo omo ilè Ìjèbú nilé lóko ni odún Agemo kàn.

Ní àtijó, ìpò Olódùmarè ni a gbó pé àwon Ìjèbú fi Agémò sí. Ìtàn tilè fi hàn pé àwon òrìsà yòókù fi ìgbà kan gbógun ti Agemo nítorí wón ń jowú ipò rè gégé bi olórí. Sùgbón bí wón ti tiraka títí, won kò lè ségun Agemo. A lè fi ìtàn yìí wé bí àwon òrìsà ti gbógun ti Olódùmarè ní ojó kìíní. Bí Agemo ti se pàtàkì tó nílè Ìjèbú hàn nínú oríkì Ìjèbú pé –

“Ìjèbú, omo Alárè

Omo Agemo òfú yòwò yòwò

Ewé dúdu oróro…”

[B] BÍ ODÚN AGEMO SE WÁYÈ

A kò tíì lè so pàtàkì bí odún Agemo se wáyé. Ìdí nip é orísìírísìí ìtàn ni ó wa lórí ìsedá odún Ágemo. Àwon ìtàn wònyí máa ń yàtò síra won gédégédé tó béè tí yóò fi sòro láti fi owó mú òkan.

Ìtàn kan so fún ni pé láti Ilé-Ifè ni òkòòkan àwon olójà Agemo ti dide. Kálukú won tè dó sí ibi tí wón wà dòní. Ní odún kan ni Awùjalè se àpèje fún won ní Ìjèbú-Òde, tí àwon náà sì sàdúrà fún oba. Gbogbo àdúrà tí wón se fún oba lódún náà ni ó se. Ìdí sì nìyí tí Awùjalè fi ń pè wón jo lódoodún láti wá máa se àdúrà fún òun. Ìtàn kan bí odún Agemo se bèrè nìyí.

Ìtàn mìíràn so pé látí Adó (Ekìtì) ni Agemo ti wá, tí ó sì dó sí agbègbè tí a mò sí Ìjèbú-Imusin fún ìgbà díè. Kò yé nib í ó se jé bí Agemo se dé Ìjèbú Òde. Sùgbón olójà Agemo kan (Olójà Nópà) wà ní Òdo-Nópà, ní Ìjèbú-Imúsin.

Ìtàn mìíràn fi yé nip é tègbón-tàbúrò ni Agemo àti ‘Awùjálé’. Awùjalè jé eni kan tí ó máa ń gbàdúrà ìdákéjéé sí Elédà rè láràárò àti lálaalé. Sùgbón agogo ni Agemo máa ń lù láràárò àti lálaalé ní tirè. Èyí máa ń dí Awùjalè lówó nígbà tí ó bá ń gbàdúrà rè. Nitorí èyí, Agemo kó lo sí Odò-Aye ní èbá Imùkù, ní tòsí Ìjèbú-Òde. Láti ibè ni òun àti àwon àtèlée rè tí ó fón káàkiri ti máa wá ń bá Awùjalè seré lódoodún ní Ijèbú-óde. Títí di òní sì ni Olójà Bájèlú Olúmùkù ti Imùkù máa ń lu agogo irú èyí tí Agemo máa ń lù ní ìjósí.

Alàgba Ògúnbawo, Omo Olúmosàn tún ní ìtàn tí ó yàtò láti so nípa bí Agemo se dé ilè Ìjèbú. Àlàgbà Ògúnbawo gbà pé láti ìdílé òkan nínú àwon ayaba Sólómónì ni a tí mú Agemo wo ilú Jerúsálémù, láti Ìjíptì (Egypt). Gbájúmò obìnrin kan, ayaba sóbà ni ó sì mú òrìsà Agemo wá láti Jerúsálémù sí ilè Ìjèbú. Alàgbà Ògúnbawo tilè tóka sí àwon òrò kan tí ó gbà pé kì í se èdè Ìjèbú, tí àwon alágemo yá láti inú èdè Ijíptì àti tí Jerúsálémù. Fún àpeere, ó ní “Eèèkeèè” tí àwon Alágemo ń lohùn já sí “En que” tí ó túmò sí “e bilà”.

Síbè, àwon mìíràn ní òrìsà tí Obáńta mú wá láti Ilé-Ifè ni Agemo. Sùgbón a kò rí èrí tó láti gbé àwon ìtàn yìí kí a fi lè mo okodoro-òrò. Lójú olóye Tàmì (olórí Agemo?), a kò lè mo bí Agemo se wáyé, Òun kò gbó o rí kì a máa so ìtàn ìsèdá Agemo, nítorí bí ìgbà tí a ń se ìwadìí ìtàn ìsèdá Olódùmarè ni yóò rí tí a bá ń wádìí ìsèdá Àgemo. Ólóyè Tàmi gbà pé “àwámárídìí ní ìsédá Agemo”.

Lójúu tèmi, ó dájú pé òrìsà Agemo tí wà ti pé ní ilè Ìjèbú. Se bí àwon kan ni ó pilè wà nilè Ìjèbú kí ó tó di pé àwon kan wá bá won láti ìbòmíràn. Bí ó ti seé kí àwon àkòhùnrìnwá yìí mú èsìn àjèjì wo ilè Ìjèbú, béè náà ni ó seé se kí wón bá èsìn ibílè àwon onílè gaan. Ohun tí ó mù mi so èyí nip é, a kò lè fi gbogbo ara gba gbogbo àwon ìtàn òkè tí ó ń so pé ibì kan ni a ti mú òrìsà Agemo wá. Nípa pé Ilé-Ifè ni Agemo ti wá, tàbí pé Obańta ni ó mú Agemo wo Ìjèbú, ó sòro láti gbàgbó. Ìdí ni pé, ó ti di àsà ní ilè Ìjèbú láti máa só àwon ohun ìsènbáyé mó òrísun’ méjèèjì yìí. Kálukù tí ó bá fé kí àwon ènìyàn tétí sí ìtàn òun ni ó sì máa ń topasè àwon orísun wònyí nítorí wón gbà á sí nnkan iyì tàbí ògo pé nnkan tiwon náà tan mó Obáńta, tàbí Ilé-Ifè.

Òjògbón Oyin Ògunbà (1967) lè so pé –

“… Tí a bá ní kí a so pàtó ohun tí a rè

nípa ìsèdálè Agemo a ó so pé Agemo tí wà

láíláí ní ilè Ìjèbú kí Obánta tó dé.

Ó tilè seé se kí ó tó egbàá odún kí obańta 

tó dé, ki ó tilè jé pé ń se ni … Obańta … so ó di tirè…” Bóyá ìdí nìyí tí a fi ń ki Agemo pé –

“Òrìsà èé róbaá mù,

róba mí bo ó”

(“Òrìsà tí oba kò mò, tí oba ń bo)

Ó lé jé pé nígba tí awon àtòhúnrinwá yìí (Obańta?) dé ni wón bèrè sí se àyípade sí èto odún náà, tí kálukú fi wá ń so orísìírísìí ìtàn.

Ní kúkúrú, èròo tèmi nip é ó seé se kí orísà Agemo jé òrìsà àpilèni tí àwon tí ó ti wà nílè Ìjèbú láti ìgbà láíláí-orúko yòówù kí àwon ènìyàn náà máa pe ara won. Lóná keji, kì í se pé kò seé se kí òrìsà Agemo jé àtèkèèrèwá súgbón ó dájú pé ójó òrìsà náà ti pé púpo nílè Ìjèbú. Bí ó bá se Obańta ló mú u wá, èyí tit ó egbèta odún séhìn bí ó bá sì se ayaba Sébà (Queen of Sheba) ni ó mú u wá láti Jerúsálémù lódò Oba Sólómóní, ó tí lé ni egbèwá odún.

[D] OHUN TÍ IFÁ SO NÍPA AGEMO

Níwòn bí Ifá ti jé ‘Akéréfinusogbón …. ….òpìtàn ilè - Ifè.

A-kó-ní-lóràn-bí-ìyékan eni…”, ó ye kí a lè mo òkun tí ó níí so fún wa nípa òrìsà Agemo.

Ese Ifá kan nínú àmúlù odù ÒTÚÚRÚPONGBÈ se àlàyé bí ó se jé tí Agemo kì í se òrìsà tí wón fi gbogbo ara mò níbòmíràn àfi ilè Ìjèbú.

“A ń pon mógbè

Mógbè ń pòngbá

A dífe fÓlomo-takìtì gbegbàá…”

Olómo-a-tàkìtì-gbegbàá ni orúko mìíràn tí a ń pe Agemo. (Lórí isé tí enì kan bá ń sé, tabí ìwà tí ó bá ń hù ni Ifá máa fi ń pe olúwarè). Ifè Oòdáyé ni Agemo wà télè; idí tí a sì fi ń pèé ní atàkìtí-gbegbàá nip é Olomo féràn láti máa ta òkìtì púpò. A máa ta òkìtì débi i pé ó máań fo àwon nnkan gíga gíga.