Orile-ede Naijiria

From Wikipedia

Orile-ede Naijiriya

Gbadamosi Temitope Thomas

GBADAMOSI TEMITOPE THOMAS

ORÍLE ÈDÈ NÀÌJÍRÍYÀ

Ìrìn àjò orílè-èdè Nàìjíríà bérè láti bíi igba odún séyìn, nígbà tí àwon òyìnbó aláwò funfun bíi: potugí, Gèésì, Jamaní ati béèbéè lo, se àbèwò si orílè-èdè adúláwò. Ara àwon ohun tí o gbéwon l’ókàn tí wón fi wá ni ohun àlùmónì ti ó sodo si ile yìí. Ara àwon ìgbésè kíní tí wón gbé ni láti rán àwon oni ìyìnrere èsìn kristiani wásí orílè-èdè yii. Nígbà ti àwon oníwàásù wònyí dé, òpòlopò omoilè yìí ti o tétísí ìwàásù won ni ayípadà débá ti wón si di onígbàgbó òdodo. Èsìn yì gbalè l’ókàn àwon ènìyàn orílè-èdè yi débi wípé won kòmo ìgbà ti àwon aláwò funfun wònyí ki òròo òwò bòó. Ilé isẹ́ ti ó kókó woo orílè-èdè yìí ni amò sí Royal Niger Company. Ilé isé yìí ni óra òpòlopò ohun àlùmónì bíi: kòkó, eyìn(epo),èpà,oje-igi (róbà) ati béèbéè lo, ti yóò si fi sọwó sí ìlú òyìnbó l’óhún. Látàríèyì, ilé isé yìí kanáà raa ìlú èkó pa ti ósì soó di ibùdó àwon aláwò funfun ni orílè èdè Nàìjíríyà. Fúnìdíèyí, nígbàtí ó dii odún 1914, gúúsù orile èdè yii darapò mó àríwá ti àpapò rè si ńjé NÀÌJÍRÍYÀ. Enití ówà léyìn orò tí óhún dún yii ni àhún pè ni Sir Fredrik Lord Lugard. Èwè, orílè-èdè Nàìjírìyà ti di ti àwon òyìnbó gèesì pátápátá báyìí, tí ìjoba ati ìsàkóso rè náà sì wà lówó won. Sir Fredrik Lugard dá ìjoba alábẹ sékélé kan sílè léyìn odún 1914 èyí tíí òpòlopò nínú àwon òùnse-ìjoba wònyí sìjé aláwò funfun ti díè nínú won sìjé aláwòdúdú. Lára àwon aláwò dúdú wònyí ni ati ríí àwon oba alayé bii: Aláàfin tí ìlú Òyó, oba ti ilè Benin, sultan ti ilu sókótó ati béèbéè lo. Sùgbó nígbà tí ódi odún 1922 ti Sir Hugh Clifford gba ìjoba, àbùkù débáá ìjoba ti Lugard dásílè. Èyi l’ómú kii Hugh Clifford dáá ìjoba míràn sílè tí ósì fi ààyè gba ìdìbò alábe sékélé. Funidièyí, àwon omo orilè-èdè yii tí ówà ni ìlú Èkó ati Calabar tí ósì ńgba tóó ogún póhùn l’ódún ní ààyè àti dìbò. Ìjoba Sir Hugh Clifford jé ìjoba tí ópé jùlo ni sáà àwon òyìnbó wònyí, nígbà tí ódi odún 1946, Sír Arthur Richard gba ipò lówó Hugh Clifford. Àbùkù míràn tún báá òfin tilè yii nítorí àléébù ti ówà nínú rè. Àláébù yii nipé, òfin kò fi ààyè gba gbogbo omo orílè-èdè yii tí ó tóó dìbò lati kópa. Sir Richard látàríèyí wá dáá òfín míràn sílè tí ókó gbogbo gúúsù ati àríwa orílè-èdè yii papò l’ábé ìjoba kannáà, èyí tí òfin tilè kòfi ààyè gbà. Ní odún 1951, Sir John Macpherson tún gba ìjoba l’ówó Sir Richard ti àléébù míràn tún bá ìjoba tirè náà. Sir Macpherson náà dáá ìjoba kan tí ófé fi ara pé Àpapò(Fédírà) sílè Sùgbón ìjoba rè yìí kòfi esè múlè rárá ti asojú si àwon ìletò tii ilè Gèésì fii pe ìpàdé àpapò látáríi èdè àíyédè tí ó bé sílè l’áàrín àwon ènìyàn gúúsù ati ti àríwá oríle-èdè yi. Asojú si ìletò Gèésì yii ni orúko rè ńjé Oliver Lyttleton, ohún ni ó yanjú dàrúdàpò yii nígbà ti o dáá ìjoba àpapò sile ní odún 1956. Léyìn odún mérin tí ìjoba ati òfin Oliver Lyttleton fesè múlè, ìdìbò gbogbogbò wáyé ni odún 1959, oríle èdè Nàìjíríyà gba òmìnira ni odún 1960. Àmó tí abá wòó njé òmìnira wà ní orílè èdè Nàìjíríyà l’òní bí?