Owo Eje ni Soki

From Wikipedia

ÌTÀN INÚ OWÓ ÈJÈ ti Kola Akinlade NÍ SÓKÍ

Yorùbá bò wón ní “ojú la rí, òré ò dénú” Ìfé tí a sì fé adìe kò dénú, kò ju ibi kí akó o ní eyin je lo. Ó se é se kí ó jé pé ojú òwe òkè yìí ni Akínlàdé mú wo àwon ìsèlè àwùjo - Yorùbá, èyí tí ó wá bí itàn àròso Owó Èjè tí ó ko ní gbèyìn-gbèyín ìgbésùnrawo àwùjo rè.

Ìtàn inú ìwé yìí dale orí àwon ìwà òdaràn tí à bá lówó tolórí-telémù èdá àwùjo. Bí ó tílè jé pé – Súlè ài Bísí jé olólùfé méjì tí wón pinnu làti fé ara won sílé gégé bí tokotaya; ikú Súlè ni kò jé kí wón lè mú àlá won se. Bísí ń sisé omo òdò lódò Àlàké nígbà tí Súlè àti Jímóò: èkejì rè jé ìgbìrà tí wón wá sí ilè Ondó gégé bí àtìpó. Àwon méjéèjì ń gbépò nínú ilé ti Bàbá Wálé fún won

Baba Wálé tí ó jé olórí àti omo onílè ní Abúlé ajé tí wón tún ń pè ni Súàrá Owóyemi fún òpòlopò ènìyàn abúlé ajé ní ilè tí wón fi dáko. Oko Bàbá wálé fúnra rè, enú-kòròyin ni. Olówo ni. Òun ni ó sì fún Súlè ní ilè tí ó fi dáko ní Abúlé Ajé. Lórénsì Awólànà tí ìnágije rè ń jé “Élíeèlì” tí ó ti fi ìgbà kan pa okùnrin kan tí orúko rè, ń jé Mósè Odúnewu ní Musin pèlú òbe, tí ó sì sá wá sí Ondo ni Baba Wálé fé gbà bíi dérébà okò tí ó sèsè fé rà.

Bákan náà, òpòlopò wàhálà ni Ògúndìran tí ìnagije rè ń jé ‘Ekùn tí se láti fé Bísí sùgbón pàbó ni ó ń yorí sí. Kódà ó be Àjíké egbón Bísí pèlú owó sùgbón Súlè Ìgbirà ni okàn Bísí fàmó pátápátá.

Sé awofélé bonú, kò jé kí á rí ikùn asebi ni òrò Bàbá Wálé tó gba Súlè àti Jímò sí ilé rè. Bí ó tilè jé pé àkísà ni Súlè wò dé abúlé Ajé sùgbón tí inú ire Bába Wálé so Súlè di ènìyàn, àse ohun tí Baba Wálé yóò se ń be nínú rè. Baba Wálé fún Súlè ní emu onímájèlé mu nínú ilé e rè Bàba Wálé pàápàá mu nínú emu yìí sùgbón ó dógbón lo aporó sí tirè léyìn-ò-reyìn nílé ìgbònsè. Ó sì bi emu tí ó mu yìí sùgbón Súlè kò rí aporó lò sí májèlé tí ó je láìmò yìí. Lójó náà ni Súlè kú. Nibe bákan náà ni Olóyè Olówójeunjéjé ti fún Súlè, Joséfù, Bàbá Wálé àti ‘Lànà ní obì je, béè gégé ni Lànà fún Súlè ní sìgá mu sùgbón Jóséèfù ní òun kì í mu sìgá.

Wàyí o, wàhálà dé, Bísí ń japoró ogbé tí àwon ènìyàn ìká sá a nítorí pé ó mò pé ènìyàn kan ni ó sekú pa Súlè Ìgbìrà tí ó jé olólùfé òun. Ó pe àkíyèsí àwon òtelèmúyé sí ohun gbogbo tó selè lórí òrò ikú Súlè. Ó sì fé kì Akin Olúsínà àti Túndé Atopinpin bá òun mú òdaràn náà tí ó pa Súlè.

Àwon agbófinró àti àwon òtelèmúyé bèrè isé ìwádìí nípa ikú Súlè. Wón fi òrò wà Àjíké lénu wò, àti àwon tí òrò náà ló mó lésè bíi Jóséèfù, Lànà, Ògúndìran, Jímò, àti Bàba Wálé gan-an tí ó jé òdádá. Ní gbèyìn-gbéyín pèlú òpòlopò akitiyan àwon òtelèmúyé-Akin àti Túndé ní ojà Olórunsògo níbi tí wón ti ń mu emu, òrò tí wón fi etí kó ràn wón lówó púpò, èyí tí ó sì fi Baba Wálé hàn kedere gégé bí eni tí ó pa Súlè nítorí àtijogún oko kòkó Súlè. Sàngbà fó, “aféfé fé, a ti rídìí adìe” owó te Bàbá Olówó Èjè.