Egbe Orun
From Wikipedia
J.G. Fágborún (1982), ‘Egbé-Òrun’, láti inú ‘Àyèwò Ohùn-òrìsà Egbé-òrun ní Ágbègbè Ifè’, Àpilèko fún Oyè Bíeè (B.A) ní Department of African Languages and Literatures, OAU, Ifè Nigeria, ojú-ìwé 1-17.
EGBÉ-ÒRUN
Contents |
[edit] OHUN TÍ ÀWON ÒNKÒWÉ WÍ NÍ SÓKÍ
Ní ìbámu pèlú àgbékalè ìwádìí yìí, a le pín ohun tí àwon ònkòwé ko gbogbo lórí EGBÉRUN sí ònà méjì - òrò nípa àwon òrìsà olómoyoyo àti ohun tí won so lórí òrò Yorùbá nípa Egbérun.
Òpòlopò àwon ònkòwé lórí àsà Yorùbá ló ti fi èrò Yorùbá àti ígbàgbó won nípa Egbérun hàn. Jéjé àti Dáramólá gbà wí pé kò sí ìyàtò láàrin Egbérun, emèrè àti àbíkú.1 Bákan náà ni èrò yí àti ti R.C. Abraham rí.2
Gégé bí òrò Smith, àlàyé tó wà lórí èsìn kò le kúnná tó bí a kò bá ménu ba àyíká ibi tí a wà tórí òun ló bí èsìn.3 Ohunkóhun ló le jé àpere òrìsà bí ó bá sá ti le hùwà tó mú okàn ènìyàn wá rìrì nígbà kan rí. Òkánkán ibi tí ohun ìyanu bá ti selè báyìí náà ni a máa ń so di ilè mímó tàbí ohun tí a mò sí ojúbo òrìsà.4 Fún ìdí èyí, kò ye kí ó yà wá lénu láti rí Egbérun tó rò mó igi abàmì, odò, òkè/òkuta torí àkíyèsí àyíká eni fi hàn pé nnkan kan gbódò máa gbé inú won kí oba òkè tó le fi irú olá tó ga béè wò wón tó mú won ta egbé won yo.
Láti túbò jérìí gbe eléyìí, Ògínní gba òrò so láti enu “Bally Yerkovich” pé Ìjèsà gbà gbó pé ebora inú ìrókò máa ń wo àse funfun tí yó sì máa kiri ní ògbánjó.5 A rí akérémedè mìíràn ti kì í kóhùngbe léèrùn. Irú eléyìí gba àkíyèsí ló jé kí wón di ohun bíbo bí òòsà.
Àwon ònkòwé mìíràn gbà wí pé àwon àbàmì igi àti òpè wònyí jé ibùgbé àbíkú.6 Wón ní irú àwon àbàmì igi wònyí ti gbàbòdì. Frazer so pé èyí ló fà á tí àwon gbégilódò fi máa ń pèsè fún irú igi béè tí wón bá fé é gé won fún pákó lílà.7 Ellis àti gbogbo àwon ònkòwé tó gbà wí pé èmí àbíkú ń gbé inú igi, òkè àti adágún odò kò jayò pa, sùgbón ó ye kí ó yé won pé kì í se gbogbo omo tí ń gbé ibi wònyí ni omo burúkú, gégé bí ìwádìí yìí se fi hàn. Àìgbà pé omo rere wà lódò òrìsà olómoyoyo ni kò jé kí Ellis ó le so pé a le toro omo lówó òrìsà tí a mò sí olómoyoyo.8
Àlàyé Adéoyè pegedé díè nípa eléyìí.9 Òun gbà pé a le toro omo lówó òrìsà tó je mó igi òun òpè. Ó ní obìnrin tí Ìretè - Àáyá (àpapò Ògúndá kan àti Ìretè kan) bá yo sí gbódò lo be òkè kó le rí omo bí. Eni tí Ìretè méjì bá ye sí ìrókò ni yó lo bo. Òsun ni eni tí Èjìogbé bá yo sí yó bo. Ohun tí a rí gbá mú níbí ni pé àwon oníwò le so pé kí abiyamo lo bo òrìsà olómoyoyo kí ó lè rí omo bí.
Abímólá tóka sí Egbérun gégé bí òrìsà nígbà tó so pé Kóórì jé olórí Egbérun.10 Ó ní ènìyàn a máa bo Ëgbérun láti rí omo bí. Ilésanmí náà kín òrò yí léhìn torí ó ní ibi tí won kì í bá ti í bo Kóórì ni wón ti ń bo Egbé èwe, lára egbé èwe yìí máà ló so pé omo olómitútù wà, èyí tí Òsun jé Ìyálóde fún.11 Ìyen ni pé ipò Kóórì ni Egbérun wà. Bí a bá fi eléyìí wé òrò Abímbólá tó ní Kóórì ni òrìsà kokànlérúgba nílè Yorùbá, a jé pé òrìsà ni Egbérun náà; torí Kóórì ni olórí Egbérun.12
Fátúbí Verger náà sòrò nípa àbíkú àti Egbérun.13 Nínú òrò rè, ó ménu ba bí àbíkú se ń yan ìpín lórun àti bí omo aráyé se ń pa kádàrá won dà léèkòòkan. Ó ní ‘Ìyájánjásà’ni kì í jé kí àwon èwe dúró pé láyé. A ó tún sòrò nípa ìyá yìí níwájú. Orí ohun tí Verger gbó láti inú Ifá ló gbé isé rè lé. Ó se àkíyèsí pé bí àkókó tí àbíkú bá dá bá fi le yè késé, kò ní í kú mó, sùgbón sá àwon “Egbé ara Òrun” yé gba agbára tí àbíkú náà ń lò. Òun náà gbà wí pé àwon àbíkú a máa ti òrun wá á ba mó etídò tàbí èhìnkùlé bí wón bá ń wá egbé won tó wà láyé kiri. Ifá nìkan ni Verger gbà wí pé ó le fi ònà dídá-àbíkú-dúró hanni gégé bí ó se hàn nínú Odù “Òsé Omolú.” Ó ménu bá ìpèsè tàbí àpèje tí àwon ará Dàhòmì (Republic of Benin) máa ń se fún Egbérun àti òrìsà ìbejì láti tù wón lójú. Ohun tó so níbi kò yàtò sí ohun tí àwon Ìyálómo náà ń se nínú ètò òrìsà olómoyoyo lásìkò àjòdún Egbé.
[edit] ÀKÍYÈSÍ NÍPA OHUN TÍ ÀWON ÒNKÒWÉ
Kò sí eni tó rántí so pé Egbérun kárí gbogbo àwa èdá ayé nínú gbogbo àwon tí a ye isé won wò. Egbé-Òrun tó jé àbíkú tàbí emèrè nìkan ló je wón lógún.
Won kò pààlà tó yanjú sí ààrin àbíkú àti emèrè. Omo elégbé ni àwon méjèèjì, sùgbón òkàn yàtò sí èkejì. Fún àpeere, Jéjé àti Dárámólá gbà wí pé òkan náà ni àbíkú àti Egbé-Òrun. Wón so eléyìí ní ìbèrè àlàyé won, sùgbón nígbà tí wón dé ìparí àlàyé won, wón ní kì í se gbogbo àbíkú ni elérè omo. A gbà béè, sùgbón ó ye kí won sì gbà wí pé kì í se gbogbo emèrè náà ni àbíkú gégé bí a ó se rí i ni iwájú.14
Àwon ònkòwé kan kò tóka sí àjosepò tó wà láàárín omo tí a toro lówó òrìsà olómoyoyo àti Egbérun.
Adéoyè gbà wí pé a le toro omo lówó òrìsà, sùgbón ó ní kò sí àbíkú.15 Ó yà wá lénu pé Adéoye yí kan náà ló gbà pé omo elégbé wà. Ó ní bí Odù Ifá “Atè nínú Ìlosùn” bá jáde sí aboyún, elégbé ni omo tó máa bí.16 Sé òun kò mò wí pé bí a kò bá tu omo elégbé lójú dáadáa yó di àbíkú.
Abímbólá àti Ilésanmí nìkan ló so pé a le tu Egbérun lójú lódò òrìsà, pàápàá lódò Kóórì tó jé òrìsà àwon èwe. Àwon fi àjosepò yí hàn díè. Wón gbà wí pé a le bo òrìsà elémo-yoyo láti rí omo bí àti láti dádìí àbíkú. Ára ohun tí a fé topinpin nínú ìwádìí yìí nìyen.
[edit] OHUN TÍ IFÁ WÍ NÍPA EGBÉRUN LÉKÙÚN RÉRÉ
Bí a bá ń fé èrí pàtàkì nípa ìtàn ìgbà ìwásè lórí Egbérun, òdò Ifá ló ye kí a lo. Ìdí nip é gbogbo ohun tó selè láyé àti lórun ló sejú Òrúnmìlà “baba elésé-oyán.”
Ifá ni a gbó pé ó kókó pìtàn àwon Egbérun. Se òun ni “akéré-finú-sogbón òpìtàn-alè-Ifè.” Ìtàn tó pa nípa emèrè ló fa òkikì rè tó lo báyìí:
“Òdùdù tí í du orí elémèrè
Ó túm orí eni tí ò sun-àn se.”17
Láti dá àbíkú dúró tàbí láti du orí rere fún àwon emèrè tàbí elérè omo, àwon oko a máa fa aya won fún babaláwo láti tójú, bí wón bá ti lóyún. Wón ní ìgbekèlé pé nípa rírú ebo ìgbà gbogbo fún aboyún béè, àwon èmí emèrè kì yó le pa orí rere tí omo tuntun náà ń bá bò wá sí ayé dà sí burúkú. Eléyìí náà ni a pè ní díduorí emèrè.
Níbi tí Òrúnmìlà mo àsírí àwon Egbé-Òrun dé, ó pìtàn orísirísI nípa won. Gégé bí òrò Ifá, Egbé-Òrun náà wà gégé bí egbé ayé náà ni. Nínú gbogbo àwon òrìsà àti ebora tí ń be ní ayé yìí kò sí èyí tó jé pé ilé ayé ni ó ti sè, bí kò se pè òrun ni elédàá ti fi àbá rè ránsé kó tó dip é a dá nnkan òhún sí ayé. Eléyìí rí béè nípa ohun gbogbo tó fi kan òkè, odò, igi, ènìyàn àti eranko. Kì í se pé nígbà tí ayé wà láyé tán ni wón déédé selè. Òrun ni ohun gbogbo ti sè wá sí ayé.
Àwon Egbé-Òrun tí a ń wí yìí, bí ènìyàn kan bá ń bò wá sí ayé nínú egbé rè ni yóò ti dìde tí won yó ti yàn án wá sí ilé ayé. Gégé bí egbé ayé se rí yìí náà ni, sùgbón tiwon ní àse láàrin ara won àti lórí ara won ju egbé ayé lo, torí ìwà bó-bà-jé-à-tú-ká pò nínú egbé ayé. Àdéhùn tí àwon egbé-òrun bá se won kì í jé kí ó yè, bí o ti wù kú ó rí.
Enì kòòkan tó wà láyé ló ní enì kejì lórun. Bí èyí tó wà lórun bá se rere, dandan ni kí èyí tó wà láyé náà se rere, torí, wón ní bí a se ń se láyé náà ni wón ń se lórun.18 E gbó bí Ògúndá soríire se wí nípa àwon ¬bòròkìnní òrun.
“Ó ní ayé sí
Ayé ń relé
Ìgèsin-òrun parí esin dà
Wón n ròrun.
Agbébatárìn ni ó soko alágbe
A difá fún bòròkìnní ayé
A bù fún tòrun.
Bòròkìnní òrun
Kì í jé kí táyé ó té
Tó bá kù dèdè
Tí tayé é bá té
Ni wón yó bá ké sí àwon tòrun
Pé bòròkìnní òrun gbà mí
Tayá ń té lo.
Òun náà ni wón fi ń sorin ko pé:
Egbé e mó mò jé n té o
Ènìyàn rere kì í tó bòrò
Égbé e mó mò jé n té o
Ènìyàn rere kì í té bòrò.”19
Eléyìí fi hàn pé bí ènìyàn bá mo Egbérun rè í tù dáadáa won a máa ranni lówó láyé láti se àseyorí.
Orísirísi Egbé-òrun ni Ifá tóka sí. Egbé rere wà, béè náà ni a rí egbé burúkú. Omo tó bá ń lo tó ń bò ni won ń pè ní ÀBÍKÚ. Òun náà ni Ifá pè ní omo Olójú-méjì.20
Àwon náà ni Ifá pè ní olè-òrun.21 Emèrè tó ń yún àyúnbò òrun náà ni a n pè béè. Gégé bí olè, se ni wón ń wá kó erù lóde Ìsálayé lo bá àwon egbé won lórun.
Irú won le lo nísisiyìí kí ó tó di pé ìyá won lóyún mìíràn. Wón le gbé àwò kan náà wá, wón sì le pààrò àwò. Bí ó bá jé obìnrin ni ìrìn yí, ó le wá ni okùnrin ni àtúnwá ayé. Ó le se eléyìí títí yó fi so ìyá rè di “onígbá-kí-lò-ńtà.”
Gégé bí Odù Ifá ATÈNÍNÚ-ÌLOSÙN se wí; àwon Egbé-òrun náà ní olórí. Ifá náà so pé:
“Saworo jìngbìnnì
Ó di jìngbìnnì saworo
A dífá fún Ìyá-jánjásà
Tí í solorí egbé lóde Òrun.”22
Ìyá-Jánjásà ni olórí egbérun kan. Ìgbà tí àwon omo egbé rè tí ó bá ń bò láyé bá kóra jo, Ìyá-jánjásà yó bi kálukú léèrè ibi tí ó bá ń lo. Eni tí ń lo sí Ìko-àwúsí, yó wà á wí. Elòmíràn a ní òun ń lo sí Òdòdòmù-àwúsè; elòmíràn sí apá Ìwonràn (níbi ojúmo tí í mó wayé). Òmíràn a ní òun ń lo sí Meréntélú Mèsànkáríbà ní Ìbámu pèlú bí orílè ayé se jé.23 Won yó sì ti mo ibi tí wón ń lo; bí lódò Oba ni bí lódò aboríkùrá ni. Won yó dá gbére ìgbà tí wón yó padà. Elòmíràn lo dá odún méta, Elòmíràn, osù méfà, ó sì le jé odún kan péró. Won yé ti fi àmì sílè nípa ikú ti wón bá fé kí ó pa àwon bí àkókò bá tó torí aráyé le féé dènà.
Ohun tí wón fi jé olè ni pé gbogbo nnkan tí wón ti fi ń sèké won láti ojó yìí wa ni won máa sà jo sára.24 Kíkú tí wón bá kú báyìí, gbogbo ohun èlò wònyí ni yó padà dà bí won se wà télè nígbà tí emèrè bá dé Òrun Àbíkú. Wón kérù dé nìyen.
Òkan lára àwon Odù Ifá tó tóka sí àwon “olè-òrun” yìí àti bí aráyé se já won ní tànmóò ni ÒSE-MÒÓLÚ (Òsé kò morí olú).25 Ó wí pé:
“Odosápéyoró;
Àrònì sí làbà yoògùn
Bónìí ó se rí;
Òla kì í rí béè;
Ní í mú babaláwo dífá oroorún,
A dífá fÉníki
Tí ń fomi ojú sògbérè omo.
Odesápóyoró;
Àrònì sí làbà yoògùn.
Bónìí ó se rí
Òla kì í rí béè
Ní í mú babaláwo dífá oroorún
A dífá fún Mójùwón Eníki
Odesápóyoró;
Bónìí ó se rí
Òla kì í rí béè.
A dífá fÓdébíyìí
Ode Ilé Eníki.” 25
Ìlú kan ló ń jé ìlú Ìki. Òrìsà tí wón ń sìn níbè ní òrìsàálá ló ń jé Ìkí.26 Ìki yìí ló kókó joba ibè bí atelèdó.
Nígbà kan Oníki (oba ìlú Ìki) ló dífá wón so pé kí ó rúbo kí Mójùwón omo rè tó ń se àbíkú máa baà se àbíkú mó. Ó ti bí Mójùwón kú tó bí èèmefà rí kí ó tó gbúròó ebo yìí. Ó gbó rírú ebó ó rú.
Ode kan sì wà nílé oníki tí orúko rè ń jé Odébíyìí. Ojú rè ni Mójùwón ti máa ń kú. Ó di ojó kan ode yìí go dé àwon eran tó máa ń je ìje àfèèmójú. Ó di èèkan ló ń gbó wújé wújé; àfi gbàgàdà gbàà ilèkùn, gbàà! Ni àwon kan bá ń kí ara won ku àbò sí ìpàdé nínú igbó kìjikìji. Wón hó yee. Wéré wón ti teni. Eni tí àpótí tó sí ti fi jókòó. Wón gbé àga olórí won sí ààrin, kóówá ń bósí iwájú láti se ìpinnu. Ó kan Omojùwón; òun náà dá àkókò. Ó ní bí igi ìdáná àkókó ba ti jó tán ni òun ń padà bò.27 Kí won tó gbé òmíràn ti iná òun yé ti padà. Ó ní bí eléyìí bá tàsé terí àwon aráyé náà a máa dógbón kúókúó; won a ní àwon ń di ènìyàn lónà nnkan; ó ní bí òun bá ti ga kan àtérígbà28 ni kí wón wá mú òun. Ó ní bí eléyìí bá wá á tì, paríparí gbogbo rè nip é nígbà tí òun yó bá lo sí Ilé-oko ni kí won wá á mú òun. Ó ní lójó Ilé-oko kòla ni kí wón rán ejò láti wá á san òun je. Ó ní eléyìí kò ní tàbí-sùgbón nínú. Báyìí ni kálukú se ìlérí àti àdéhùn lórí májèmu ohun tó máa gbé ilé ayé se. Léhìn náà ìlèkùn tì padà. Wón padà sí ibi tí wón tí wá. Ojú Odébíyìí ni gbogbo rè se.
Ìrúbo ti Oníki se ni kò jé kí Egbérun mò wí pé ode kan wà lórí ègùn tó ń wo ìse àwon. Ode délé, ó so ohun tó rí fún Oníki. Se ó sì ni àkókò tí àbíkú máa ń bó sínú aboyún. Ó so fún oba pé lónìí s’la, obìnrin re yó bímo.
Àwon awo so fún won pé se ni kí wón fi ìtì ògèdè ti igi ìdáná. Bí igi bá jó tán, ìtì ògèdè kò le jó.
Bí ó se wí yìí náà ni wón se. Nígbà tí ó di pé igi yó jó tán ni àwon Égbérun ránse dé. Ni wón bá ń fi ìyèrè ké sí Mójùwón:
“Wón ń se Mójùwón o ò
Omo Eníki.
Emi ló se táwa ò rí o mó?
Ìwo Mójùwón
Omo Eníki
Emi lé se táwa ò rí o mó.”
Ní òun náà bá fi ìyèrè dáhùn.
“Ó ní n bá tètè wá o ò
Èyin egbé mi
Odébíyìí ni kò mò jé n wá mó
N bá mò tètè wá
Èyin egbé mi
Odébíyìí ni kò jé ń wá mó.”
Báyìí ni wón se tí wón padà séhìn. Wón lo jísé pé enì kan tí wón n pè ni Odébíyìí àbí nkan ní ó dabarú àbá rè.
Ó tún bù se gàdà, Oníki lo béèrè pé se omo yìí kò ní í kú. Àwon awo so fún un pé kí wón já òkánkán enu-ònà kan òkè àjà. Kí ó má sí à ń bèrè kí a tó wolé mó. Wón se béè.
Nígbà tí Mójùwón dàgbàdàgbà tó dé déédé kinní tí wón já yen ló bá bèrè sí í nàgà. A ní òun tilè férè ga kan kínní yìí. Se ènìyàn kà sì le ga ga ga kí orí rè kan ilé. Báyìí ni owó pálábá se tún se mógi.
Nígbà tó té ilé-oko í lo, wón dífá wí pé se omo yìí bá esè rere dé ilé-oko? Àwon awo so fún wón pé eni tó ń lo sí ilé-eko yìí eèrà kò gbódò mò, Aso oko òun èwù oko ni ó gbé dé ilé-oko. Dìgbàdìgbà ni wón gbé e dé ilé-oko torí kò fé ètò tí wón se yìí.
Gbogbo àdéhùn métèètà ló yè. Báyìí ni Omójùwón ko se kú mó. Oníki ni béè ni àwon awo òun wí.
“Ode Sápóyoró.
Àrònì sí làbà yoògùn.
Bónìí ó se rí,
Òla kì í rí béè;
Ní í mú babaláwo dífá, oroorún.
A fdífá fún Mójùwón,
Èyí tí ó se omo Eníki.
Odesápóyoró
Àrònì sí làbà yoògùn.
Bónìí se rí
Òla kì í rí béè,
A dífá fún Odébíyìí
Ode ilé Eníki
Njé Méjùwón omo Eníki
Emi ló se táwa ò rí o mó?
N bá tètè wá
Éyin egbé mi
Odébíyìí ni kò jé n wá mó.”25
Ifá yìí tóka sí irú ìlérí tí àwon emèrè máa ń se àti bí wón se ń mú ìlérí won se. Ifá dídá lóòrèkóòrè ló kó Oníki ye lórò ti àbíkú omo yìí. Ó hàn pé bí ohun tí emèrè yàn bá fi le tàsé kò le kú mó. A rí i pé léhìn tí obìnrin bá ti soyún tán ni àbíkú tó ó máa ń bó sínú won.
[edit] GBOGBO EGBÉRUN KÓ NI OLÈ-ÒRUN
Odù Ifá Ògúndá - soríire náà ló tún pàtàn oríire tí í se omo oba ÈWÍ ADÓ. Ojú omo ló n pón Oba Eléwìí nígbà náà tó fi lo dífá. Wón ní kí ó rúbo kó le baà bí oríire lómo.
Ògúndá soríire so pé:
“Alubàtá ní í fègbé wòlú
A dífá fún ÈWÌ Àgbádó
Omo Ayó-gbìrì-gbiri-ògùròńsékù
Wón ní kó rúbo
Kó le ba à bí oríire lómo.”29
Àsìkò yí náà ni Oríire náà ń múra láti wá sí ilé ayé. Òun náà to àwon awo Òrun lo, wón kì fún un pé:
“Igi-ganganran má gún mi lójú
Òkèèrè téfé ni wón ti í kèèwò rè
A dífá fún oríire,
Tí gbérù nikòlé ayé.
Wón ní tó bá délé ayé
Kó wálé olórò kó sò sí.”
Oríire gbó rírú ebo, ó rú. Ó so fún àwon Egbérun rè ohun tó fé é se yìí. Àwon kì í sòwó àbíkú. Ó ní òun ń lo sòwò láyé ni. Àwon egbé rè náà sì so pé àwon yó ràn án lówó.
Àwon méjìdínlógún ló wà nínú egbé yìí. Wón mú adìe òsòòró kòòkan pèlú egbeegbàá wón fi ta oríire lóre. Wón ni kó mú lára rè sanwó oníbodè kó lo fi ìyókù sòwò láyé. Ò gbó ohun tí àwon awo rè wí ló se kó wonú-obìnrin Eléwìí tó fi lóyún, torí wón ní kò gbódò dé sí ibi kan ìdákúdèé láyé.
Oríire dàgbà tán, ó sisé sisé kò rí èrè isé jé. Ajé kò su fún un kó. Ó tálákà ju èkúté sóòsì. Bó se èyí, a di jábúté, bó se tòhún, ijábúté. Enu bèrè sí í ya àwon ènìyàn. Àsà nígbà tó ń bò tó gba adìe métàdínlógún àti egbàá métàdínlógún, wón ti bá a se àdéhùn pé bí ó bá dára fún un láyé, kó má se méní, kó má se méjì, kó sì fi ohun ìní kóówà ránsé sí i. Gbogb nnkan wònyí ni wón dì sínú ara oríire gégé bíi dúkìá.30 Oríire dáyé ó fowó rogi ìgbàgbé. Kò mo ohun tó yàn lórun mó. Isé oríire kò ní àkójo torí kò mú ìlérí egbérun rè se. Ara ìlérí rè ni pé bí ayé kò bá dùn, wéré ni òun yó padà, sùgbón àwon Egbérun kò rí Òdúlàdé, won kò rí Eégún.31 Fún ìdí èyí, okùn ayé Oríire tí wón so, won kò tú u sílè.
Bí Oríire bá lo sí oko-awo wón le so pé kí ó rú ewúré tàbí eyelé, awó tàbí etù. Owó tí won yó sì so pé kí ó fi lé e, le jé òké kan dípò iye tó je egbérun rè.
Ìgbà tó yá, àwon awo tó kì fún Eléwìí kí a tó bí Oríire tún wá á kì fún un. Wón ní kí ó lo rèé wá adìe metádìnlógún tó mo ní ìwòn àsésìn pèlú egbàá métàdínlógún. Wón kó gbogbo rè sínú àgè, ó di etídò. Ebo àrúdà tí wón pè, ó ti pé àwon Egbérun jo. Wón gbé ebo lo lójú won.32
Gbogbo nnkan tí Oríire se lófò, àsé òdò àwon Egbérun rè ló ń rogún sí; láti san èsan fún Oríire, wón gbé àpò àgbìrà tí wón ń gbágún ire tó ye kí ó jé ti Oríire wá sí ilé rè. Lásìkò yí náà ni àwon awo ní kí Oríire dá àpò àgbìrà kan kí ó máa so owó sínú rè kí ajé le mó on lówó33. Wón bá a da ìyèròsùn díè sínú rè. Wón ní kí ó máa fi irú owó béè ba enu kí ó tó fi sínú àpò tó gbé kó. Wón bá a sefá sí i lára.
Ká má pà á pírí, ìgbà yí padà sí rere fún Oríire.
“Báyìí ni Oríire bá ń jó
Ní ń yò.
Ó ní béè ni àwon babaláwo
Òun wí.
Álubàtá ní í fègbé wòlú
A dífá fún Èwí Àgbádó
Omo Ayó-gbìrìgbiri-ògùrò-ńsékù
Wón ní kó rúbo
Kó le baà bí Oríire lómo.
Ó réyelé ogún
Ó rágùntàn ogbòn.
Ó tu àtù-kelele kèsù.
Igi-ganganran má gún mi lójú.
Òkèèrè féfé ni wón ti í kèèwò rè.
A dífá fún Oríire
Tó ń tìkòlé òrun bò síkòlé ayé.
Wón ní tó bá délé ayé
Kó wálé olórò kó sò sí.
Ó délé ayé,
Ó wolé olórò ó sò sí.
Ajé mò wá ń se nímòrun àgbìrà