Aboyun

From Wikipedia

ABOYÚN LÈ MO OSÙ ÀTI OJÓ BÍ Ó BÁ FE

Mo bólómo jó,

Mo sùn láwùjo omo,

Pe-ké-lé-pè-ke,

Mo bólómo jó.


Olórun dá awa ènìyàn, ó sì fún wa ní Èdè láti fi ronú fa orísìírísìí ìmò jáde nípa ìgbésí ayé wa, sùgbón ìwà àìlè-se ara eni, àìsòótó, àìlè-kó-ara-eni-ní-ìjánu àti àìgboràn tó pa aráyé àkókó ré ní ìgbà ayé “Núà”, mú kí òpòlopò ànfààní ìmò ìjìnlè nípa omo bíbí farasinko fún awa omo ènìyàn. Ìlò ogbón àtòdò Olórun wá náà ló mú kí àwon Òyìnbó lè wá àwari okò òfurufú àti iná mònàmóná kàn tí àwon Yorùbá sì se kánàkò àti àféèrí, bí ó tilè jé wí pé akùretè ènìyàn ni àwon asòyìnbó di Olórun kà wá sí bí a kò bá ti lè so iye ahá àgbo tí ó wo ètè tàbí làkúrègbé sàn. Òmùwè kan kò lè we òkun já ni òrò àwarí ilé ayé yìí jé.

Orísìírísìí mérìíìírí àti mégbòórí ni a lè ronu se ìwádìí rè ní ìgbésí ayé wa fún ìlosíwájú èdá. A tilè gbó wí pé àwon Òyìnbó gbìyànjú láti dá ènìyàn sùgbón Olórun fi juju bò won lójú nípa àwárí náà. Lójú àwon elòmìíràn àwon Òyìnbó ń wádìí Olórun ló jé. A tún gbo pé àwon Òyìnbó ń wá ònà láti fa àtò ara òkùnrin si ara obinrin ki obirin si lóyún láìjé wi pé wón ní ìpàdé pèlú ara won. Kìí sé pé àwa náà kò ní ìrírí tí a lè ronú gùnlé fún ilosíwájú omo adáríhurun, bí eré bí eré àlàborùn ń di èwù, sùgbón àwon Òyìnbó ń pa ogbón ré mó wa nínú ni. Bí a rérìn-in bí èrín-ínkò dún hòhò won a ní erin-ín “fànákúlà” la ń rín. Ó ye kí a mú ìwà àbùkù wònyìí kúrò. N kò so wí pé tí a bá rí ohun tó dára nínú ogbón àwon àjèjì kí a má mú un lò torí pé omodé gbón àgbà ni a fi dá ilè Ifè. Èyìí ní emi náà se kí ń tó le ní ìmò àpilèko yìí so fáyé gbó.

Láìbá òpò lo sí ilé olórò, bákan náà ni a se ń gba bímo ní àgbáyé sùgbón àsà ìsekúse bí ajá lo yàtò sí ara won. Láti ìgbà ìwásè Yorùbá ni ìtìjú àti ìwà ìséra-eni nípa ìbálòpò oko àti aya sùgbón eke ló dáyé tí sá áà fid é Apòmù ló mú kí omo Oòduà máa gun ara won bí ajá, kí wón sì tún ń bímo lódoodún. Èyí lòdi sí ònà tí Olórun fé fún ìlóyún àti ìbímo tó péye gégé bí ìmò tèmi. Ní àfikún, nínú ìwe “Bíbélì onígbàgbó”, àwon “Júù” pèlú fi ara mó àsà iwà bí Olórun nípa ìbálòpò oko àti aya gégé bí a ti se ri à kà nínú ìwé “Korinti” Kíní orí ogun (I Corinthians 6:20) ó tóka sí i wá pé mímó ni ibálòpò okùnrin àti obìnrin ní láti jé. Gégé bí ìrírí mi, tí a ba lè pa òfin ìséra-eni mó nípa ìbálòpò toko-taya a ó mo ojo tí a lè dá ìsé omo tuntun àti ojó tí a ó bí I, Òwe wí pé kò sí eni tí ó lè mo oyún ìgbín nínú ikarawun kò wáyé níbí yìí rárá.

Mo fo lo tààrà sórí òrò mi kí àwon asòyìnbó di Olórun ènìyàn máa so pé mo ń jagun enu láti so iró di òótó ni. Otító gbáà ni gbogbo arímò mi lórí òrò yìí gégé bí ìrírí mi. Mo mú Ironú Òyìnbó àti ti Yorúbà lò nínú àrímò náà tori pe àjeje owó kan kò gbérù dé orí, òtún we òsì, òsi we òtún ni owó fi ń mó.

Gbogbo wa ni a mò wí pé osù, onkà se ìkewàá ni olè omo ń gbà nínú ìyá rè kí a tó bí i. Sùgbón ojó mélòó pàtó ni ònkà tó se ìkewàá yìí? Ibè ni idárúdàpò wà tí mo fe mú kúrò. Àwon babańlàwa kò fi dándan se ìwádìí iye tí ojó ònka sikéwaa kò fi dandan se ìwádìí Òyinbó tó si gbiyànjú lati sírò re, ìsekúse ati allo-mú-ídi-rè kó-jé ki won rí ìmólò iye ojo da gbé ojó ònì. Àwon onkòwé nípa omo bíbí, fún àpeere nínú ìwé tí won pe ní Iwo àti Omo Re- “You and your baby” pàte ìlóyún àti ìbímo báyì:


Ojó Ìlóyún Ojó Ìbímo

Osù Sére 1 7 Osù Òwàrà

8 14

Osù Séré 15 21 Osù Òwàrà

Osù Séré 22 28 Òwàrà

Osù Séré 15 4 Osù Belu


Gégé bí ìsirò òkè yìí, òrìn-lé-lúgba ojó (23) days) ni wón so pé omo ń gbé nínú oyún. Èyí jé ogóji òsè onígbàgbó Síwájú sí i àwon onkòwé tún so pé aboyún lè bímo ni òsè kan síwájú tàbí séhìn òrìn-lé-lúgba ojó tí wón wí náà (270 to 290 days). Èmi kò fi ara mó èyí torí wí pé ònà wà tí a lè fi mú ojó ìbímo yanjú ju èyí lo tí a bá tè lé ìséra-eni nípa ìbálòpò toko-taya ní ìlànà tí Olórun fé.

Gégé bí a ti mò, osoosù ni obìnrin tó bàlágà ń se nnkan osù rè. Wúnrèn osù náà yóò sì parí ní ojó kerin sí ojó karùn-ún tí kò bá sí ìdí burúkú kan. Gégé bí àwárí mi nípa òrò yìí, ojó ketàlá sí ojó kerìnlá tí obìnrin bá bèrè nnkan osù rè, tí ó já sí wí pé ojó kejo àti ojó kesàn-án tí ó parí rè, ni ó lè lóyún tí yèkínnì kan kò lè yè é tí èjè oun àti oko rè bá bá ara won mu, tí won kò sì ní àìsàn tàbí àrùn kan lára. Ìdí abájo ni pé ojó ketàlá sí ojó kèrinlá tí obìnrin bá bèrè nnkan osù rè ni yóò yé eyin tí ó lè fi lóyún. Eyin yìí kò sì lè gbé ju ojó kan lo kí ó tó kú. Bí ó se jé pé okùnrin àti obìnrin ló ní láti pà de kí oyún tó lè dé, eyin tí okùnrin yé tí a ń pè ní àtò lè gbé tó ojó méjì péré kí ó tó kú. Èyí fi hàn wí pé tí okùnrin àti obìnrin bá ní ìbálòpò nì ojó ketàlá àti ojó kerìnlá tí obìnrin tí rí nnkan osù rè, àtò okùnrin àti eyin tí obìnrin yé náà yóò se kòngé ara won. Gégé bí isé Olórun, obìnrin náà yóò lóyún tí kò bá sí ìdí buburú kan bí owó ayé tàbí àìsàn. Àìlè mú ara dúró toko-taya ló jé kí a máa so wí pé kí a se é tí tí ní torí pé a kò mo èyí tí yóò di òun. Tí ó bá di àkókò tó ye kí obìnrin náà rí nnkan osù rè láàrin ojó keèdógbòn sí ojó kejìdínlógbòn tí kò bá rí i, a jé wí pé Olórun ti gba aájò rè nùun.

Iye ojó pàtó tí o ye kí omo gbé nínú oyún jé ojó méjìdínlóòódúnrún (298 days) tí a bá tè lé ònà tí Olórun fé jù lo nípa ìbálòpò toko-taya. Ìsekúse, sìná, àìsàn, àrùn, àìse oyún jíná àti ogun òtá ló lè mú kí a máa bí omo ní ojó tí ó dín tàbí tí ó lé sí ojó tí mo wí yìí bí ó tilè jé pé àfòn náà lè gbó kí ó tó wò bí isé àánú Olórun sí wa.

Léhìn ìbálòpò toko-taya fún ojó méjì tí a yàn laàyò fún ìlóyún náà, won yóò sírò ojó méjì-dín-lóòódúnrún síwájú. Ojó náà ni aboyún náà yóò bímo tí kò bá sí ìdíwó nípa ohun tí mo so ní òkè síwájú. Fún àpeere, tí ó bá jé pé ojó kìní àti ojó kejì osù kìní odún (1st and 2nd January) ni wón sun oorun ìdasèé omo náà, dájúdájú ojó ìkúnlè aboyún náà yóò jé ojó kerìn-lé-lógún tàbí ojó keèédógbòn osù kéwàá odún (24th or 25th October).

Nínú ìwádìí mi, àwon ènìyàn díè fi ara mó ohun tí mo so sùgbón ní àfikùn mo gbó pe léhìn ìbímo méta, àkókò tí obìnrin ń rí nnkan osù rè lè yí pa dà sí ti àtèhìn wá. Bí ó ba jé béè, síbè èyí kò yí ohun tí a so níp àtimo ojó ìbímo pa dà. Ohun tí eni náà ní láti se ni kí ó gbé ìsirò yen lé ìgbà tó rí nnkan osù rè. Ní ìdàkejì èwè, Yorùbá bò wón ní omo beere òsì beere. wéwé ni omodé ń bí omo rè, yàtò sí ti omo eku edá. Bóyá èyí tilè sípayá sí i wí pé omo méta ni Olórun pèlú tilè fé kí toko-taya má bi. N jé tí a bá bí méta náà kò tit ó, kí èjè ara toko-taya lè simi, ki won lè nípon láyà jeun omo di ojó ogbó. Ní ìdà kéta, ìrírí fi han wí pé léhìn ìbímo bíi méta náà ni obìnrin ń ní èrò láti dóko jù lo. Won a ní oko kan kò kún kóńbóòdù àti wí pé eni tí ó ní oko tí kò ni àlè mó on kò lè ní ohun tí egbé ń ní. Won a sì gba èjè oníran-n-ran mó ti won lódò àwon àlè won láti fib a èjè ti ara won jé. Àkókò yìí pèlú ni àwon òsóóró abíléko ń yó lo sé oyún olóyún tí oko wón lè fura sí. Oyún sísé náà sì lè ba ilé omo won jé. Ó lè fa kí obìnrin ya àgàn tàbí kí ó máa ní oyún ànísé tàbí kí bíbí omo rè máa se ségesège bí esè agree.

Àwon kan tún so pé omokùnrin ń fi ojó márún-ún pé nínú ju omobìnrin lo. Èyí kò rí béè rárá. Se bí a ń bí Ibejì, èta òkò àti èrin oye bí won yóò jé tokùnrin-tobinrin. Sé tí won bá bí obinrin lóníí ó lè di ojó karùn-ún kí won tó bí okùnrin ni? Èyí mú mi rántí awon to n so wí pé eegun ihà mésàn án ni okùnrin ni tí obìnrin si ní eegun ìhàn méje kí to di wí pé ìmò wa gbòòrò pe iró pátá ni èyí.

Lóòótò oyún nínú kì í se àrùn sùgbón ìbá dára bì aboyun bá lè pa ìdí mó ní àkókò wònyìí ni ìgbà ìlóyun fún ire olè aboyun náà. Tí aboyun kò ba pa ìdí mó ní osù kejì ìlóyún ó lè fa ki oyún ya. Mo gbó pé osù karùn ún pèle se elegé fún aboyún tí ó bá ń ni ìbálòpò pèlú okùnrin. Tí aboyún bá ń se sìná, ó lè ko orísìírísìí àìsàn bá olè inú rè. Mo rò wí pé èyí ló mú kí àwon babańlá wa da ogbón so wí pé tí aboyún ko bá ka eni tí ó bá se sìná kò ní í lè bimo náà pèlú àlaafíà ní ojó ìkúnlè rè.

Ó se pàtàkì fún aboyún láti je ohun tí ó dára bí èfó, eyin àti èso. Ó ní láti wà ní ìmótótó nipa ìtójú ara, oúnje àti ibùgbé. Aboyún ni láti lo òògùn aremo dáa dáa kí omo náà lè jé eni tí a sè jiná láti inú oyún. Òògùn aremo náà ní láti bèrè kí obìnrin tó lóyún rárá, èyí pèlú ló lè mú ara obìnrin náà dá sáká kí ó tó lè lóyún bí ó ti se ye. Oko pàá-pàá ní láti lo òògùn kí ara rè lè dá sáká bí I ti ìyàwó rè. Tí a kò bá se òògùn oyún fún aboyún, nínú òfíì àti òláà ni omo páńdòrò ń gbo sí ni irú olè béè ń wà nínú kí ìyá rè tó bí i ní àpàpàndodo. Ó lè jé omo olósù méje tàbí òkú-omo. Nítorí ìdí èyí, àwon òògùn alamo bí òògùn èdà, ayóbi, òkà, ìju, inárun àti èélá se pàtàkì fún aboyún. Bí ó bá lo àwon òògùn náà, bòn-ùn ni omo inú rè yóò maa ta. Òògùn abíwéré wà fún ìtorí ojó ìkúnlè, kí ó máa ba à á sòro. Irú òògùn báyìí máa ń je mó èbè àwon àgbà, osó, abínú-eni àti aseni-bá-ní-dárò tó wà ládùúgbò kí aboyún náà lè bí wéré. Sùgbón ó se ni láàánú pé àwon sòyìnbó-dí-Olórun àti àwon tí ó gba wèrè mó èsìn lòdi sí ìlò irú egbògi tí mo so sókè yìí. Èyí sì jé òkan pàtàkì tí o ń mú kí ojó ìbímo won se segesège. Ohun tó bá bá ilè mu ni a ń gbìn si i. Iwo omo Oòduà, má se tan ara re je. Lo òògùn alamo kí o si tè lé ìlànà ìbálòpò toko-taya bí mo ti se àlàyé rè síwájú yen, dájúdájú iwo yóò mo ìdásèé omo re àti ìkúnlè pèlú.

Kí ni ànfáàni tó rò mó kí toko-taya mo ojó tí won lè dásèé omo won àti ojó tí won lè bímo? Ìbàlè okan yóò wà fún toko-taya tó bá mo ojó tí won lè bímo àti pàá pàá tí kò tilè ní í si wàhálà púpò torí pé won tí tè lé ònà tí Olórun fé jùlo nípa ìlóyún náà láti ìbèrè tí tí dé òpin. Toko-taya yóò lè sa gbogbo agbára won láti múra sílè fún omo tuntun náà. Orúko bí i Abísónà tàbí abísójà kò dè ní í sí mo. Ìwà àgbèrè yóò dínkù láàrin omo Oòduà àti ní gbogbo àgbáyé tí wón bá lè mú ìwà ìlóyún náà lò. Àrùn bí àtòsí àti jeeríjèèrí yóò dínklù láàrin agbo wa. Ìséra-eni nípa ibálòpò toko-taya yóò gbòòrò, kò dè ní í sí gígún lójoojúmó bí ajá nípa pé a kò mo èyí tó lè di omo. Ìfé ìfokàntàn-án ara eni yóò si gbile láàrin toko-taya. Ìlóyún àìròtelè yóò dínkù, omo bibi yóò sì fi ètò sí ara rè láì òòògùn oyún sísé tí ó lè jé ìlòdì sí òfin Olórun. Ní ìparí a ó lè dá ìsé omo wa pèlú inú dídùn àti ogbón mìíràn tí ó lè mú ki omo náà se orí rere ni ojó ayé rè yàtò sí omo tí a dá ìsé rè láìmo àkókò náà. Bóyá ní ìgbà tí inú baba kò dùn sí ìyá rè. Bó yá léhin tí a mu otí yó tán tàbí ní àkókò tí a wa nínú àìsàn tó lè ran ìgbésí ayé omo náà sí buburú.

A sà á, a ni kò jé ewé rè ni kò pé. Dán an wò ló bí iyá òkéré. Bí a bá se é bí mo ti wí, yóò ríí bí i ti í rí, bí toko-taya bá lè jáwó nínú ìwà àgbèrè tí akorin onílù kete kan ko nipa obìnrin báyìí pe:


Ìyá oko re ló bá e wi no?

Ó ló tì.

Bàbá oko re ló bá e wí no?

Ó ló tì.

Ègbón oko re ló bá e wí no?

Ó ló tì.

À bí oko re kò dè ká e lára?

Ó ní hen en èn én,

Mé è dè gba kín-ín-kín.

Àbò mi rè é.


Ijàdùola, J.O.


ÌTÓKASÍ

1. Àdunní F. Ìjàdùola: Ìfowó-sowòpò rè pèlú mi gégé bí toko-taya.


2. Anderson: Your guide to health, ojú ew

3. Gertrude Nystron: Christina Romance and Marriage

4. Rev. Father Ilesanmi àti Ògbéni Òpéfèyítìmi: Ìdánilékòó won nípa oyun nínú àti omo bíbí

5. Margaret F. Myles: Text book for Midwives, 9th Edition page 83.

6. Rosemary E. Bailey: Mayes Midwifery, 9th Edition pages 127-128.

7. M. Duncombe & B. Weller: Paediatric Nursing

8. Mary M. Anderson: The Anatomy and Physiology of Obstetrics, Sixth edition.

9. You and your baby: A Guide to a happy pregnancy and child care. Publiched by: West African Book publishers Ltd., P.O. Box 3445 Lagos, Nigeria. 10. J.R. Ludlow: About Your Marriage

11. R.T. Cross: Making the home happy

12. Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania and New York Brooklyn, New York, U.S.A

13. Mrs. Nweke – University of Nigeria, Nsukka.

14. Mrs. Aderounmu - Oba Ademola Hospital Abeokuta.

15. Mrs. Idowu - Oba Ademola Hospital, Abeokuta.

16. Mrs. Walkson – Seventh day Adventist University of Ife.

17. Master Taiwo – Medical Student, University of Ife.