Iwe Akonilede Ijinle Yoruba 1

From Wikipedia

Akonilede Ijinle Yoruba

Adebisi Aromolaran Oyebamiji Mustapha (1976), Akómolédè Ìjìnlè Yorùbá Lagos Macmillan Nigeria Publishers Ltd. Ojú-ìwé = 15.

ÒRÒ ÌSAÁJÚ

Méta ni a pín òwó ìwé yìí sí, eléyìí sì ni àkókó nínú won. Èrò wa, gege bi olùkó akónilédè Yoruba ati olùdánniwò ni pé ìwé náà yóò wúlò fún awon akékòó ní ilé-èkó gíga ti Girama ati ilé èkósé olùkóni. Bákan náà, ìwé yìí yóò jé kòseémánìí fún awon tí ńgbaradì fún ìdánwò G.C. E. nínú èdè Yorùbá.

A ti se àkíyèsí wí pé kò tíì sí ìwé tí ó se àlàyé àsà ìbínibí pelu gírámà èdè Yorùbá gege bi ati se le ko ó ní òde-òní yékéyéké tó béè, ní àrówótó àwon olùkó ati akékòó. A se àgbéyèwò orisirisi èka òrò Yorùbá l’óríkèé ní èdè Yorùbá pón-m-bélé ní ònà ìròrùn tí ó le yé akékòó. Béè sì ni a wo ìsesí àwon òrò Yorùbá ati isé tí wón le se nínú gbólóhùn, ní onírúurú, láìfi ara èdè àwon ènìyàn tabi ìran mìíràn.

Èyí nìkan kó; a tún se àsàrò lori àwon àsà wa lati ìgbà ìwásè títí di òní olónìí. A rí i wí pé a kò le pé ayé di ayé òlàjú kí á wá kùnà lati bu olá fún àwon àsà ìbínibí tí àwon baba-ńlá wa fi nse gbajúmò lati ojó láéláé wá. Ìdí rèé tí a fi jíròrò nínú ìwé yìí lori àwon àsà wa bi mélòó kan laì ní àbùlà. Ònà kan nìyí tí a le gbà gbé ògo orílè-èdè wa ga.