Egbe Ogboni ati Egbe Ode

From Wikipedia

Egbe Ogboni

Egbe Ode

IPA TÍ EGBÉ ÒGBÓNI ÀTI EGBÉ ODE KÓ NÍNÚ ÈTÒ ISÈLÚ ILÉ YORÙBÁ LÁTI ÀTIJÓ

Egbé Ògbóni jé egbé kan tí o je mó òsèlú lára àwon egbé tó tún ya láti inú egbé yìí ni Èlúkú àti Orò wà. Ara àwon olóyè Ògbóni sì ni Olúwo, Apènà, Ìwàrèfà, Àró, Àpérín, Òdòfin wà. Olóyò obìnrin tó se pàtàkì ni Erelú, se tako-tabo ni nnkan dùn, èyí ló fà á tí a fi ń gbó pé “Òsùgbó ò le dáwo se láìsí Apènà àti Erelú. (Ògbóni kannáà ni wón ń pè ní Òsùgbó ni apá Egbá àti Ìjèbú). Lónà kinní, inú egbé yìí ni àwon afoba je ti ń wá, àwon ni a pè ní ‘Iwàrèfà’ àwon ni wón ni isé bí Oba titun yóò se dé orí oyè ní ìròwó-ìròsè.

Lóòótó ni egbé ògbóni ń fi Oba je, wón tún ní agbára láti ro Oba lóyè tí ìwà rè kò bá ti bá ti ara ìlú mu, níwòn ìgbà tó sì jé pé àwon ògbòni náà ni asojú ará ìlú, mu náà nìyen, wón ní agbára lórí ikú àti ìyè Oba pàápàá jùlo ní agbègbè Ègbá àti Ìjèbú tí ti so télè. Kò sí àníàní pé láìsí eni tí yóò máa ká Oba lówó ko báyìí yóò si ipò náà lò.

Àwon omo egbé Ògbóni náà ló ń sin òkú Oba tó wà jà, àwon olóyè ìlú títí ken àwon omo egbé won. Iyì ńlá ló sì wá jé láyé àtijó pé àwon omo egbé Ògbóní ló wá sìnkú bàbá enìkan. Bí ejó kan bá selè ní agbo ilé tàbí ládùúgbò kan tí baálé ilé àti olórí àdúgbò parí rè tì, ó di tìlí nìyen, irú ejó báyìí lè jé lórí ààlà ilè láàárín eniméjì tàbí láàárín àdúgbò méjì, ó sì lè jé òrò ogún pínpín tí ó le débi pé omo bàbá méjì n sààgùn síra wón, ibi tí òrò iwájú Ògbóni wá le sí nip é o jèbi ni o, o jàre ni o, èyin méjèèjì ló gbódò fi owó àti otí díè jura ná kí e tó sèsè wá rojó. Eni tó bá jèbi wàyí yóò sèsè wá san owó ìtanràn, tí kò bá rí i san, àwon ebí rè lè fara gbá mbè bí béè kò, ó lè di títà lérú. Nítorí ìdí èyí àwon oníjà kì í janpata lórí ejó tí kò téjó mó, tí wón bá ti rí eni bá wón só, won yóò ya jé kó tán síbè. Àsé bí osò àti àjé ti lágbára tó, wón tún lóko, àwon àgbà ní “tàtkíté ka, èbiti ka, èbìtì tí ò gbójú kò le è pàgbín”. Àsé bí eba kò bá tí ì dun omodé ni yóò maa bùyàá àgbàlagbà, bí owó ìyà bá tè é tán Olóun á wo Táyé wo Kánìn ló kù tí ó maa se, owó bá te àwon ará ibí wònyí, àwon ògbóni lè so pé kí àwon omodé sòkò pa wón wón sì lè fi orò gbé won.

Bákan náà, gbogbo àwon alápámásisé, àwon ajègboro dàgbà ni àwon Ògbóni ń kì mólè tí wón ń tà lérù, nídìí èyí, gbogbo ebí ló n kìlò fún àwon omo wo kí wón jáwó nínú òle ní íse. Ní ti àwon ode wàyé o, igi kan kò le dágbó se, bí ó bá jé àwon ògbóni lásán ló ń gbìyànjú láti se òpòlopò isé ìlú, isé náà ìbá kà wón láyá, èyí ló fà á tí àwon odé se ń ràn wón lówó tí àwon méjèèjì sì ń fowó sowópò. Isé àwon odé je mó isé owó eni lápá kan béè ló sì tún je mo ìlú síse lápá kejì. Ara àwon olóyè ode ni Olúode, Asípa, Balógun, Òtún Balógun, Òsìn Balógun wà.

Àwon ode ló ń fi ilé àti ònà won sílè láti jagun fún ìdáàbòbò ìlú lówó òtá, sé kò kúkú sí pé jagun-jagun kan wà lótò láyé ojóun, tí ogún bá ti parí wón tún padà sénu isé ode nìyen. Nípa ogun jíjà báyìí won a kó erú àti erù fún lílò ìlú won. Àwon ode ló tun ń só òde lóru láti láti ri pé olè kò jà ní ìlú, olè ti owó bá si tè yóò máa so ohun tó rí lébò kó tó warú sówó lódò àwon Ògbóni.

Tí àsè pàtàkì kan bá selè nílùú, enu kí obá kàn ránsé si Olúode nip é ilú ń fé lo òpòlopò eran ìgbé, oba ni yóò gbé gbogbo ètù àti ànàyá tí àwon ode yóò lò kalè, Olúode ni yóò wà lo so fún àwon omo egbé rè. Gbogbo eran tí wón bá pa nírú ode síse báyìí ni wón gbódò kó lo sí ilé Oba. Àwon ode tún máa ń sin òkú omo egbé won, àmì iyì àti èye ni èyí sì jé fún àwon ebí òkú náà, won yóò lo sode láti pa eran fún síse òkú òhún, won yóò sì se ètùtù ikehin fún ode náà èyí tí wón ń pè ní ‘Isípà ode’.

Emí ìsòótó àwon ode pàápàá jé ara àwon nnkan tí a rí dìmú títí di òní olónìí. Ode kò jé gbé ode egbé rè, kò jé gbàyàwó ìyàwó egbé rè, kò jé jókòó sórí àpótí ìyàwó egbé rè, tí òrò bá dójú rè tán won a máa fi Ògún búra, ohun tí mo wá so pé a rí kó níbè nip é di òní yìí sé, tí wón bá so pé kí èèyàn fi Ògún búra nílé ejó tàbí níbikíbi, tí ó sì mò pé òótó ni òun se èsè òhún, kò ní se aláìbì séhìn nítorí pé ó mò pé Ògún kì i pé kó tó dájó.

Nípa òògùn tí àwon odé ní ti owó ba te arúfin tí wón rí i pé ó gbówó àwon ode ni wón ń késí láti mu òògùn wá dá rèria fun ibu eni béè. Nípa agbára oogun won ni wón se ń so nínú ìjáloá won pé “Ikú ò jìnnà sení ode gbà níyàwó, ìkú ò jinnà séni gbayàwó ode.” Parípárí ré, àwon ode ló ń jé kí àwon ará ìlú máa rí eran pàárò olú àti ewèbè tí won ń fi ojojumó je, yàtò sí wí pé won ta eran tí won bá pa wón tún máa ń há àwon aladuúgbo won pàápàá tí won bá pa eran ńlá bí ìgala, àti pé tí a o bá pègàn àjànàku ni a ń so pé ‘mo rí kinní kán firí, ti a bá rérin ká pé a rérin, àwon egbé méjèèjí yí kúrò nínú ohun àfowóróséhìn tí a bá ń sòrò lórí ipa tí orísirísi egbé ń kó nínú ètò ìsèlú ilè Yorùbá laye àtíjó.


AJÀNÍ JUNAID