Ounje (Onje)

From Wikipedia

Ounje

Onje

AWON ONUJE ILE YORÙBÁ

ÁDENIRAN OLAJUMOKE ABIDEMI


DEPARTMENT OF AFRICAN LANGUAGES AND LITERATURE, OBAFEMI AWOLOWO UNIVERSITY, ILE-IFE, NIGERIA.

ÌSÈSE

Kini Asà:-

Àsà je mo ìgbàgbó ó ni ohun tí àwon èyà kòòkan gbàgbó. Àsà tun je mo isé ònà ó le je èyí tí a fojú rí tàbí aláfenuso (Visual or Verbal). Àsà tun je mo èèwò (Moral teaching) fún apeere ma joko lórí odo gbogbo irú eleyìí wà fún ìmótótó. Bí a ba pa àsà bi eni pa awùsá ohun tí a o ba níbè ní esin ìbílè, eré ìbílè ìsomolórúko ìwúre, oúnje ile Yorùbá, ìlù lílù abbl. Bayi la ń se nílé wa èèwò ibòmíìran ni nítorípé àrà tí Àgbòyín ń dá kò jo ohun àrà lój;u ajá sùgbón ó le jo ohun àrà lójú ewúré. Ewúré le wa wò sùnsùn ko gba àrà yìí. Ohun tí ó je orírún àsà ni àra. AWON OÚNJE ILÈ YORÙBÁ

Orísìírìsí ounjé lo wa ni ilè Yorùbá bi, isú Àgbàdo, Èwà, gbágbùda, ìdí èyí ni àwon Yorùbá fi ń pa lowe wípé:

Ounje lòré àwò

Èdá tí ó bá jeun

Ó dájú pé sàárè tí ń

séwó pe irú ènìyàn bee.

Eyi lo fa ti àwon Yorùbá fi pa owe wípé “Òyìnbó mu tíì, mo mu èko, Omi gbígbóná kan náà ni gbogbo wa jo ń mu”. Òrò àwàdà ni eleyìí télè, sùgbón ó ti wa ń dàbí òwé, béè ni ki i se Owe rárà, òótó òrò ni. Ayé ode òní ní a ń sòrò búrédì, bota, konbufu àti sandininni. Ni ayé àtijó, àwon oúnjé ile wa nikan ní a mo, ti a si ń jé ní àjegbádùn. Se ki àgbàdo to d’áyé, ohun kan saa ní adiye ń je. Ìgbà tí Òyìnbó gòkè ti ayé sé lajú díè sí ni a bèrè si ní ri àwon oúnjé tí won ń di sínú pangolo láti í ile òkèèrè wa. Ki ó ma dabi enipe a gbàgbé oúnjé ti a ti ń je ní ile yi láti ojó ti aláyé ti de ayé, ó ye ki a le ko díè sílè nínú won fun anfààní àwon omo tí won ko le saimo gbaguda. Orìsìírìsì oúnjé lo wa ní ilè Yorùbá bi i iyan ohun si ni Yorùbá ka kun oba oúnje ilè Yorùbá ni won fi maa ń so pe Apeere

Iyán lounjé

Oka logun

Áiri rárá

La ń je eko

Kenu maa dilè

Ní ti gúgúrú…

Orisiirisi isu ni o wa, díè nínú won ní Efùrù, Òlòò, A réhìn-gba kùmò, olobe-ku-a-se-nu; petisan àti òpòlopò isu wonyí ní o dára lati je iyán nìkan; àwon béè ní isu bii, A rehin-gbakùmò, Efuru ati bebe lo. Laye ode oni tí a ba ka Obirin mewa agbara kaka ni a fi ma ri Obirin meji to mo oruko isu lójà ara àsà tí Oyìnbó ń gba dànù lowo wa nìyí nipa kìí won maa ko ounje inu agolo wa si ile wa. Díè lárá àwon isu wa ni Efùrù, Kange àti petisan. Eyi ti a ko le fi gun iyan rààrà ni Òlòò, Ewùrà ati Èsúrú. Isu oloo àti Ewùrà ko kúkú ní ki a maa fi àwon gún iyán, sùgbón ní igba pupo won dara fun isu jije. Yorùbá maa n pa owe kan nipa Èsúrú, wipe Èsúrú sàsejù o te lowo oníyán. Se igba tí ehun ba wa l’enu ni a ń ja ìjàdù èkùró yato si igba ti isu tuntun ba de olowo níí je oyin ni oro isu. Nítori ìdí èyí òpòlopò lo maa ń je kókò. Kókò náà pin si orìsI méjì a ni koko papa àti funfun meejeji ni a le fi gun iyán tabi ki a se je. Àwon mìíràn maa n se Eepa nínú kókò nípa sísá kókò yìí dára déra ni ó se le se e je téyìn èyí ó tí dí jíje niyen. Won ó ge si wewe, wón ó fi epo àti iyò si ó di jije nìyí. Nígbà mìíràn á le fi àjekù isú wònyí se èlùbó tì a o si maa ro je bi àmàlà. Ekìtì àti ìjèsà je okan lárá àwon eya Yorùbá to féràn iyan púpò. Àwon ènìyàn agbègbè Oyo àti Ìbàdàn feran Amala isu lópòlopò. Ijebu lo féràn ikokore to won n fi Ewura se. Agbado náà je òkan lára oúnjé ilè wa orisiirisi nnkan ní Yorùbá n lo fun. Won le se je lásán, won le ta je lori èyìn iná, won le fi se ògì, wón tún le fì se Àgbalà, àádùn elébúté. Yorùbá tun máa ń lo Agbado láti fi se Egbo won maa ń se bi èwà ó si máà ń pe lórí iná pupo titi ti gbogbo re yíì fi fo po mo ara won tan tí ó ba ti jiná wón, yóò bu ata si ó dí jije nìyí. Ewà tun je òkan lára oúnjé ile Yorùbá ti o wulo pupo lawujo a máà ń fi èwà se òpòlopò oúnjé bi Ekuru, Moi-moi, Èwà sísè obe gbègìrì, Àkàrà, Ikookan won lo ní bi won ti máa ń se. sùgbón díè la le fenu ba fún apeere. Èkuru èwà funfun ti ko ni eipo nínú ni wón máa ń lo lati yi se èkuru wón maa n pon sínú ewe bi moi-moi tí ó ba ti jina tan won yóò bu ata le wón yóò sI maa to bu ata si lati maa je. Yàtò sí gbogbo àwon oúnjé tí a ti menu ba yìí a ri wípé àwon òyìnbó aláwò funfun ti fe ko ba wa tan òpòlopò obirin ilé ni ko mo nnkan tí ó ń je irú, ogiri tàbí olú. Gbogbo irú àwon nnkan wònyìí lo ń mu oúnjé dùn sùgbón tí òpòlopò ko ka kun mo. Irú je okan lára Eso ti olodumare pèsè fun omo ènìyàn lati je ní awon ìyá wa ni won sábà máà ń lo láti fi se Obè èfó. Bakanna ní ògìrì efo ni won ń lo èyí náà fun, sùgbón òyínbó ti fe gba gbogbo nnkan mo wa lowo tán nípa tita Maggi oníyò eyì ní òpòlopò ń lo lati fi se obe gbogbo ohun ti won ń ko wa yìí ko se ara lanfani ó tunbo ń ko ba ara ni. Òpòopò aisan lo ń wolé si wa lára nípa kíkòtì gbogbo àwon oúnjé ti ń sara lóore fun wa. Oúnjé lore àwò.

ÌWÉ ÌTÓKASÍ

1. Ladele T. A A et al (198) Àkójopò iwadìí ijinle Asa Yorùbá Macmillan Nig. Publishing Limited.

2. O. Daramola, A. Jeje (1967) Àwon Àsà ati Òrìsà Ile Yorùbá Onibon-òjé Press Ltd.