Iyanrofeere

From Wikipedia

ÌYÁNRÒFÉÉRÉ

Ogunlógò àwon onimo ni o ti sàlàyé lórí ohun ti ìyánròfééré je, lara won ni Ògúnyemí (1988:58) so pé:

Ìyánròfééré ni kí onísé onà ménu ba ìsèlè kan ni sókí nínú isé rè. Orísirísi ònà ni onísé onà lè gbà yán òrò fééré nínú is isé rè, ó lè jé ìtàn ìgbà ìwásè, ìtàn àtenudénu tàbí àwon ìtàn tó je mó ìsèlè àwùjo lórísírísi ònà

Ohun tí a n so níbi ni pé ìyánròfééré je ààbò òrò èyí tí yóò di odidi nígbà tí a bá ti gbé e kalè tán. Ìyánròfééré akéwì nínú isé won láti sòrò léréfèé bí kò bá fé sàlàyé lórí kókó òrò kan délè.

Àpeere ìyánròfééré wà nínú àwon àkójopo orin oloselu àti Ewì Ajemoselu ti a mu lo nínú isé yìí. Bí àpeere nínú ewì Oládnrewájú Adépòjù ó ní:

(a) Omo amúkàrà sábé èwù je

Ado ki i wale eni kobe ònìnù monù

Kobe oninu ba ti mo nu nibè agigo agírá á rá.

(Àsomó 1, 0.I 85, ìlà 172 – 175)


Ohun tí a gbó nínú ìtàn ni wí pé ní ìgbà àtijó ni pé àwon omo Ado-Èkìtì ní ahun gan-an, a gbó wí pé wón gbádùn láti máa je àkàrà, wón ni tí won bá ti n je àkàrà lówó tí wón ba ti gburo àlejò, kíá ni won yóò ti fi àkàrà yìí sábé èwù, wón á rora máa yo je kí wón ma bá fun àlejò won tàbí elòmíràn je.

Ìtàn tún fi ye wa pé ní ìgbà ìwásè pé ole pò ni ìlú Adó, tí àwon omo Adó bá wa kí ènìyàn nílé wón gbódò ri nnkan fowó kó lo kaka kí Adó ma ri nnkan ji won yóò jí òbe tí a n lò nínú ilé tàbí agolo tábà èyí ni wón n pè ni agigo agírà. Idi niyi ti won fi n ki won ni oriki yìí.

(b) Béè bá fi dìbò fóbáfémi Awólówò lótè yìí láéláé lomo yín, ó wà nínú ìgbàdì ìgbèkùn. (Àsomó 1, 0.I 147, ìlà 98 – 99)


Ní gbogbo odún tí Awólówò lo lórí aga nígbà tí ó je olóòtú ìjoba ìwò oòrùn Naijiria ni odun 1955 si odun 1959, àwon ènìyàn ìlú mo ìgbà tirè yìí sí rere ìgbà san gbogbo mèkúnnù, àsìkò yìí ni ó se ìwòsàn òfé fún terú tomo èkó òfé fún gbogbo akékòó, ìwé òfé lorisirisi fun gbogbo àwon akekoo, ilégbèé òfé fún àwon òsìsé àti béè béè lo.

Odún 1979 ni Obáfémi Awólówò tún fe lo fún ààre orílè-èdè, tí ó sì tún se òpòlopò ìlérí fún àwon omo orílè-èdè sùgbón kò ni ànfààní àti wole. Ohun ti ó so mo ayolo ti mo yan fééré lókè yìí ni wí pé ní odún 1960 sí odún 1978 àwon ológún ni ó n tukò orílè-èdè yìí ní ìgbà náà, gbogbo nnkan ni ó le koko, ìyà n je ará ìlú, ìdí nìyí ti akéwì yìí fi n ro àwon ènìyàn ìlú nínú àyolò òkè yìí wí pé ki won ki o dìbò yan Obáfemi ki won le kúrò lówó àwon ológún má su, má tò yìí, sùgbón èròngbà akéwì yìí pàbó ló jásí nítorí Obáfémi Awólówò kò wolé fún ìdíjé náà nígbà náà. Tí a bá wá wòye gbogbo ohun tí akéwì yìí so a ó ri pé inú ìgbèkùn àwon olósèlú náà ni Nàijíríà sì wà di bí a se n so yìí.

Bákan náà ni a ri àpeere ìyánròfééré nínú àkójopò orin olósèlú tí a lò nínú isé yìí, àpeere ni:

(a) Yóó se bó ti wí o

Yóó se bo ti wí

Awólówò yóó se bó ti wí

(Àsomó II, 0.I 186, No. 60)

Gégé bí mo se so sáájú pé olóòtú ìjoba ìwò oorun Nàìjíríà ni Obáfémi Awólówò ní odún 1955 sí odún 1959, kí o tó di olóòtù ìjoba ìwò oòrùn yìí, ó se àwon ìlérí kan fún àwon ará ìlú ó ní òun yóò se ìwòsàn òfé, èkó òfé, àti orísirísi àwon ohun amáyéderùn gbogbo àwon ìlérí wònyí ni ó múse nígbà tí ó dé orí àléèfà, kò dójú ti àwon tí ó yàn-án sípò ìjoba sùgbón a ri pé nígbà tí ó tún di odún 1979, ó tún díje fún ipò olórí orílè-èdè Nàíjíríà ni gbobgo àsìkò tí wón n se ìpolongo ìbò gbogbo yìí náà ni ó tún tii n se àwon ìlérí kòòkan láti so ayé derùn fún gbogbo mèkúnnù. Ohun tí ó fà á tí àwon ènìyàn fi n ko orin ti a ko sókè yìí níyì nítorí pé Obáfémi Awólówò je eni tí ó máa n mú ìlérí se.

(b) Ta ló so pé òle ni Yorùbá

Kó wá wo bí ilé se n jó bí i papa

Kó wá wo bi omo ènìyàn ti n yò

ròrò bí àkàrà

E wet e kó yan wóró

E wet e kó yan woro

Ìgbà yi làwon òtá wa yó mò

Páwa Yorùbá kò gba gbèré

Àwa omo Yorùbá ti gòkè àgbà

(Àsomó II, 0.I 186, No. 61)

Ohun tí a yán fééré nínú orin òkè yìí ni ohun ti ó selè ní odún 1965 nígbà ìdìbò ìwò oòrùn Naijiria láàrin egbé olópe àti egbé olówó, nígbà náà lóhùn – ún a gbó wí pé egbé olópe ni o wolé sùgbón àwon egbé olówó se òjóró sí ìbò náà, èyí ni ó bi àwon egbé olópe nínú ti wón fi bèrè si nijo ilé àwon egbé olówó, omo egbé olówó tí wón bá rí nígbà náà won yóò pa á, èyí tí ó bá jàjà bo lówó won sálo kúrò nínú ìlú ni, èyí tí won kò bá ri mu nínú omo egbé olówó won yóò sun ilé rè kolè ni, bí wón ba ènìyàn níbè àjópò ni. Sùgbón àseyorí tí àwon omo egbé olópe se ni wí pé won kò gbà kí àwon egbé olówó gorí àléèfà láti ran àseyorí won yìí lówó ijoba ológun wa gun ori aleefa, inú àwon omo egbé olópe dun nítorí won ti pinnu pe kaka kéku ma je sèsé a fi sàwàdanù.