Oko-Osayen
From Wikipedia
Oko Osayen
Oko Osanyen
A.S. Salawu
A.S. Salawu (2006), ‘Àfiwé Ìtúpalè Síńtáàsì Yorùbá àti Òko-Ósànyèn’., Àpilèko fún Oyè Ph.D, DALL, OAU, Ifè, Nigeria.
ÀSAMÒ
Isé ìwádìí yìí se àfihàn àwon ìjora àti ìyàtò tó wá ní aágbon síńtáàsì èdè Yorùbá Àjùmòlò àti Òko-Ósànyèn tí wón ń so ní Ìjoba ìbílè Ògòrì-Magóńgò ní ìpínlè Kogí. Isé náà sì tún se ìfàjáde àwon àbùdá èdè káríayé àti àbùá àdání nínú òpò ìpele síńtáàsì èdè méjéèjì. Ìdí tí a fi se isé àfiwé yìí ni kí a baà lè pe àkíyèsí sí ìse pàtàkì síse àtúntò sí àtúnpínsísòrí àwon èdè ilè Aáfiríkà tó wà ní abé ìpín-èdè West Benue-Congo àti Niger-Congo.
A gba àwon àkójo-èdè fáyèwò láti enu àwon olùso tó jé abínibí fún èdè mejèèjì. A sì tún se àmúlò àtòpò-òrò onírinwó ti Ìbàdàn àti àwon ìbéèrè tó se kókó kan, tí a tò jo. Isé ìwádìí yìí tún se àmúlò àwon àbò ìwádìí ní ilé-ìkàwé láti baà leè se àgbéyèwò finnífinní sí àwon isé tó tì wà nílè. Tíórì gírámà onídàro tí à ń pè ní Tíórì Awòté-wògàba ni a lò láti fi se àfiwé ìtúpalè sí àwon àkójo-èdè-fáyèwò.
A wá se àwárí pé àwon èdè méjéèjì jora nínú àwon ìgbésè síńtáàsì bii ìsodi awé-gbólóhùn asàpèjúwe àti ìgbésíwájú àkíyèsí alátenumó. Àwárí mìíràn ni pé àwon èdè méjéèjì yàtò nínú ìgbésé síńtáàsì ìgbéséyìn àkíyèsí aláìlátenumó. Béè sì tún ni èdè méjéèjì náà yàtò lórí ipa tí ìpele fonólójì máa ń ní lórí òrò arópò-orúko àti ìyísódì won. Isé ìwádìí yìí tún ri i pé àríyànjiyàn tó máa ń wáyé lórí sílébù olóhùn àárín, àwon èdà wúnrèn gbódò àti ìrísí ìpìlè òrò-arópò-orúko eni keta asàbó nínú Yorúbá Àjùmòlò kò bá tí wáyé ràrá bi a bá ti wo isé àti irisI àwon wúnrèn wònyen nínú èdè Òko-Ósànyèn Isé yii ti gbìyànjú láti dábàá àwon ònà àbáyo sí àwon àríyànjiyàn wònyi.
Èrò isé náà nip é bi a bá fojú ijora síńtáàsì tó wà láàrin èdè Yorùbá àti Òko-Ósànyèn wò ó, a lè so pé wón sè wá láti orírun kan náà ni.
Orúko Alábòójútó: Òjógbón L.O. Adéwolè
Ojú ìwé: 361