Ekun Oro
From Wikipedia
Eku Oro
A.F. Bamidele
ÌTÀN ORÍRUN EKÙN ÒRO LÁTI OWÓ A. F. Bámídélé, UOA, Adó-Èkìtì, Nigeria.
Ekùn Òrò jé òkan lára àwon ekùn ilè Ìgbómìnà ní ìpínlè Kwara. Lára àwon ekùn Ìgbómìnà tó kù ni ekùn Àpà, ekùn Èjù, ekùn Ìrèsé, èkun Òró àti ekùn Àrán. Àwon ìlú abé ekùn Àpà ni Agbondà, Omido, Adigun, Oko-Àwòrò àti Egúdu. E`kun Àrán ni a ti rí ìlú bíì Omù-Àrán, Àrándùn, Àrá-Òrìn, àti Roré. Ní ekùn Èjù ni a ti rí Igbóńlá àti Sanmora. Ekùn Ìrèsé ni a tí ri Ìgbànà, Àdáńlá, Òfàrèsé àti Òbín. Ekùnmésàn-án Òró ni a ti rí àwon ìlú bíì Òtún-Òró, Òkèrímì-Òró, Òkè-Olà-Òró, Ìlúdùn-Òró, Agbé-Ola Òró, Irébòdé-Òró, Sìè-Òró, Ìjomu-Òró àti Ìdó-Òró.
Ekù Òrò (ekùn náà ni a ń pè ní ekù ní àdúgbò yìí) wà lára àwon omo bíbí Odùduwà tí wón wá láti Ilé-Ifè. Dáda (1965) so o di mímò pé ojó ti pé ti baba ńlá àwon ènìyàn ekùn yìí ti wá tèdó sí orí ilè tí à ń pè ní Òrò lónìí. Ìtàn yìí tè síwájú pé òkan lára àwon omo odùduwà ló wá tè é dò. Olóyè James, eni àádórin odún, so pé abé ìsàkóso Odùduwà ni gbogbo ilè tí a mò sí Òrò lónìí wà ní ìgbà náà. Nígbà tí àwon ènìyàn wònyìí dé, a gbó pé Òkè-Owá ni wón kókó tèdó sí tí wón sì kólé won sí. Olóyè James tèsíwájú pé àkókò yìí ni Ogun Agánnigàn gbilè bí òwàrà Òjò. Ogun yìí ni ó fón òpòlopò àwon ènìyàn wònyìí kiri tí won tún lo tèdó sí àwon ìlú mìíràn bíì Òrà, Òkè-Ode, Bàbáńlá àti Ògòòrò àwon ìlú mìíràn ni ìjoba Ìbílè Ìfélódùn. Ní báyìí, òpò ìlú wònyìí kìí se ara ekùn Òrò, (nítorí wón ti jìnnà sí ekùn Òrò béè sì ni èyà èka-èdè Ìgbómìnà won yàtò dé àáyè ibi kan sí èka-èdè Ìgbómìnà Òrò) wón sì máa ń rí ara won bí omo baba kan náà.
Alàgbà Arówólò làti Òmùgo, eni omo odùn métàdínlógórin) jérìí sì ìtàn tí ó so pé ó tó ogún séntúrì tí àwon ènìyàn Òrò tí sòkalè láti orí òkè Owá sí ibi pètélè ó tún tè síwájú pé nígbà tí won dé ibi pètélè yìí ni wón bèrè si kó àgó káàkiri fún àábò ara won. Léyìn tí won sòkalè ní orí òkè yìí ni wón wá so ara won di Ìdòlú, èyí túmò sí àwon ènìyàn tí wón ti wà papò ti pé tí wón sì ń gbé ibìkan náà. Ìtàn fi yé wa pé lára orí òkè tí àwon ènìyàn wònyìí ti sòkalè wá ni Òkèmure, Òkèlúwúro, Ayétòrò, Òkèdábà wá-ni-Òkèmure, Òkèlúwúro, Ayétòrò, Òkèdábà àti Òkè-Ayìn. Ní báyìí a ti rí tó ìlú méèédógún ní abé èkùn Òrò. Ìdí sì nìyí tí wón fi ń pe ekùn yìí ni akù méèdógún Òrò. Ekùn Òrò ní báyìí bèrè láti Òmùgo, àwon Ìlú tó kù ni Òkè-dába, Ajégúnlè, Ìràbòn, Àgó (Òrò-Àgó) Àhún, Òganyìn, Àgó-Olómo, Oyátèdó, Òkè-Àyìn, Òkè-Owá, Ìlàfè, Òkèmure, Ayétòrò àti Aráròmí.
Ní ìbèrè pèpè, isé àgbè àti ode ni àwon okùnrin wón ń se tí àwon obinrin sì máa ń re aró tí wón sì ń se òrí. Èsìn Ìbílè gbilè púpò ní ekùn yìí kí àwon elésìn àtòhúnrìnwá tó dé.
Àkíyèsí: A yo isé yìí láti inú àpìlèko Émeè A.F. Bámilélé