Yoruba bi Ede Akokunteni I

From Wikipedia

Yoruba bi ede Akokunteni I

Egbé Akómolédè (1996), Yorùbá bí Èdè Àkókúntení 1 Ibadan, University Press Plc ISBN 978 249 525 5.

ÒRÒ ÀKÓSO

A fi ara balè ko òwó ìwé yìí ní ìbámu pèlú Kòríkúlóòmù tuntun tí ilé-isé ìwádìí àti ìdàgbàsókè èkó ní Nàìjíríà (NERDC) sèsè gbé jáde fún kíkó èdè yorùbá bí Èdè Àkókúnteni ní ilé-èkó Sékóndìrì Kékeré ní Nàìjíríà. Sùgbón nígbà tí a pàjùbà òwó ìwé náà tán. Ó hàn kedere pé won yóò tún wúlò fún àwon tó nífè;e sí kíkó èdè Yorùbá kún èdè ti won, tí won kì í se akékòó ní ilé-èkó sékóndìrì kékeré ní Nàìjíríà.

Lára àwon tí a ríi pé yóò tún se béè wúlò fún ni: àwon akékòó ní ilé-èkó Sékóndìrì Àgbà ní Nàìjíríà tí won kò ní ànfààní láti kó èdè Yorùbá tí won sì fé kó o; irúfé àwon akékòó béè ni ilé-èkó ìkósé Olùkóni Onípò Kejì, Kóléèjì Eń Siì Lì àti irúfé àwon akékòó béè ní Yunifásítì ní Nàìjíríà. Bákan ni òwó ìwé yìí tún wà fún àwon àgbà tó ti mò-ón-ko mò-oń-kà ní èdè mìíràn ní Nàìjíríà tàbí ní orílè èdè mìíràn ní àgbáyé tí won nílò láti mo èdè Yorùbá á múlò fún isé àti ìse won. Ìwé Ìtónisónà fún Olùkó tí a fi kún un mú kí ó wúlò fún àwon olùkó èdè Yorùbá tí won bá ń kó elédè mìíràn.

Àwon omo Egbé Akómolédè àti Àsà Yorùbá Nàìjíríà tí ó ní ànfààní láti lówó sí kíko òwó ìwé yìí dúpé gidigidi lówó Egbé náà fún yíyàn tí a yàn wón; wón sì dúpé lówó Ilé-isé Asèwétà University Press Plc. Bákan náà a kò le sàì dúpé lówó Olótùú Yorùbá ilé-isé náà, Ògbéni Olúkúnlé Adédigba, fún akitiyan won lórí gbígbé òwó ìwé náà jáde lónà tó wú ènìyàn lórí.

Ibi tó bá kù sí, a ó máa sé àtúnse rè lójó iwájú ní agbára Olódùmarè, Eni kan soso tí isé owó Rè péye. Ní báyìí, a ké sí i yín, ará ilé, èrò ònà, e bá wa fi òtító-inú àti ìfé pípé gba obè yìí; kí e tó o wò; kí e sì so fún wa bí ó se rí lénu yín o. Ire kàndù!