Efon-Alaaye
From Wikipedia
Efon-Alaaye
Ìtàn Ìsèdálè Ìlú Èfòn-Aláayè Láti owó I.A. Ologunleko, DALL, OAU, Ifè, Nigeria
Nínú àwon ìwé ti mo yè wò. kò sí èyí tó so pàtó ìgbà tàbí àkókò tí a dá ìlú Èfòm-Aláayè sílè. Gégé bí ìse àti àbúdá ìtàn ìwásè. púpò nínú ìtàn yìí ló máa ń rújú pàápàá tó bá jé ìtàn ìtèlúdó ni ìle Yorùbá. (Akínyemí 1991:121) Ìlànà ìtàn àròso ìwásè ní a gbé ìtàn wònyí lé. Ní ìgbà ìwásè kò sí pé a ń ko nnkan sílè. Nítorí àìko sílè ìtàn yìí, kò jé kì a rí àkosílè gidi fún òpòlopò ìlú ní ilè Yorùbá nínú ibi tí ìlú Èfòn-Aláayè ti jé òkan nínú awon ìlú béè. Ìtàn ti a rí jójo kò kojá ìtàn atenúdenu. ìtàn ìwásè ìlú Èfòn Aláayé kò yàtò sí èyí. Orísìí òpìtàn ni a rí, ìtàn won máa ń yàtò sí ara won, bí kò ní àfikún yóò ni àyokúro òkan pàtàkì lára ohun tí àwon òpìtàn ti sisé lé lórí nípa ìtàn ilè Aáfíríkà ni ìyànjú won lati wo ìtàn ìwásè, kí wón tó lè fa òótó yo jáde. Sàsà ni onímò kan tó sisé lórí ìtàn ìlú kan tàbí àdúgbò kan tí kò mú ìlànà ìtàn ìwásè ló láti sàlàyé to bojumu nípa orírun ìlú kan (Johnson 1921;3).
Gégé bí àwon òpìtàn ilè Yorùbá, àwo òpìtàn ìlú Èfòn Aláayè gbà pé òdò odùduwà ni wón tí sè wá láti Ilé-Ifè. Lára àwon òpìtàn yìí tilè lérò pé eni tó te ìlú Èfòn-Aláayè dó rò lati ojú òrun sílé ayé. Ìlú tó sòkalè sí ní Ilé-Ifè tó jé orírun àwon Yorùbá. Ìtàn yìí sòro láti gbàgbó, nítorí kò ri ìdí múlè. Kò tí ì sí eni tí a rí tó wò láti ojú òrun rí. Nínú ìtàn ìwásè, òrìsà àti odù mérìndínlógún ni a gbó pé wón rò láti ìsálòrun wá sí ìsálayé (Abimbola, W. 1968:15). Awon òpìtàn yìí lè rò pé bóyá nítorí tí a ti ń pe àwon Oba ilè Yorùbá ni ìgbákejì òrìsà ni àwon náà se rò pé Aláayè àkókó rò sílé ayé lati òrun.
‘Omo owá, omo ekún
Omo òkìrìkìsì
Omo ò tójú òrun á yé’
Nínu ìtàn ìwásè mìíràn, a gbó pé Obàlùfòn Aláyémore ni oba àkókó ti o te ìlú Èfòn-Aláayè dó. Obalùfòn Aláyémore yìí jé omo Obàlùfòn Ogbógbódirin tí í se àkóbí Odùduwà tí ó jé Oòni ti Ilé-Ifè ni àkókó ìgbà kan. Léyìn Ikú rè, Òrànmíyàn lò ye kí ó je oba ní Ilé-Ifè sùgbón ó ti lo sílùú àwon omo rè, Eweka ni Eìní ati Aláàfin ni Òyó. Obàlùfòn Aláyémore ti je oyè Oòni kí Òrànmíyàn tó dé.
Nígbà tí Òrànmíyàn dé, Aláyémore sá kúrò lórí oyè nítorí pé ní ayé àtijó won kì í fi eni ìsááju sílè láti fi àbúrò joyè. Obàlùfòn Aláyémore rìn títí ó fi dé orí òkè kan. Won pe ibè ni Oba-òkè. Èyí ni oba tó tèdó sorí òkè sùgbón lónìí òbàkè ni won ń pe ibè.
Ni orí òkè yìí, Obàlùfòn se àkíyèsí pé eranko búburú pò ní agbègbè tó tèdó sí, èyí tó pòjù ni efòn. Ó bèrè sí í pa efòn yìí ni àparun. Awon efòn kékeré níbè ni won kójo sínu ogbà, ti won so won mólè títí wón fi kú. Omodé tó bá lo sì igbó ibi tí wón kó efòn kékeré sí, ni awon òbí won a ké pé: ‘Kó ò yàá se lúgbó efòn alaayè’
Nibi yìí ni Èfòn ti kún orúko Obalufon Aláyémore. Lára Aláyémore ni won tí yo Aláayè to fid i: Èfòn-Aláayè títí dí òní. Nígbà tí ó se Obàlùfòn Aláyémore ránsé sí Òrànmíyàn kí o fi nnkan ìtèlúdó sowó sí òun. Léyìn tí wón ti fi nnkan yìí ránsé sí Obàlùfòn Aláyémore; kò pé ti Òrànmíyàn kú. Àwon ará Ilé-Ifè wá ránsé si Obàlùfòn Aláyémore láti wá joba léèkejì. Kí o tó lo, ó fí omo rè joba ní ipò rè. Ìyàwó méta ni Aláyémore ni kí ó tó kúrò ní Èfòn-Aláayè. Àwon ni Adúdú Òránkú tí ì se ìran àwon Obólógun; Aparapára òrun ìran awon Asemojo, èèketa ni Èsùmòrè-gbé-ojú-òrun-sàgá-ìjà. Ìtàn so pé lásìkò tí Obàlùfòn Aláyémore padà sí Ilé-Ifè gégé bí Oòni, bó sí àkókò ti Oba Dàda Aláàfin Òyó wá lórí oyè ni nnkan bí 1200-1300AD. Bí ìtàn ìwásè yìí ìbá se rorún tó láti gbàgbó awon àskìyèsí kan ní a rí tóka sí tí ó jé kí ìtàn náà rú ènìyàn lójú. Nínú ìtàn yìí, won so pé Obàlùfòn Ògbógbódirin ni àkóbí Odùduwa, èyí tó tako ìtàn tí a ti mò télè nípa Odùduwa. Òkànbí ni àkóbí Odùduwa. Bó bá tilè se orúko ló yípadà, àwon omo Okànbí ni oba méje pàtàkì ni ilè Yorùbá tí kò sí Obàlùfòn nínú won. Ohun tí òpìtàn ìbá so fun wa nip é ìran Odùduwà ni Obàlùfòn jé.
Àkókò tí ìsèlè yìí se rú ni lójú púpò. Nínú ìtàn yìí a ri i pe Obàlùfòn Aláyémore mo àsìkò ti Òrànmíyàn wà láyé. A rí i pé ègbón àti àbúrò ni won. Kó ye kó rí béè, se ló ye kó je omo àti bàbá. Lóòótó ni Òrànmíyàn je oba ni Òkò, tó tún wá sí Ilé-Ifè. Àwon ará Òy;o ló fi Àjàká je oba sí Òkò. Aláàfin Dada tí òpìtàn fenu bà pé ó je oba ní Òyó da ìtàn rú. Johnson (1921:144) gbà pé Àjàká ló wá lórí oyè gégé bí Aláàfin Òyó nígbà tí Òrànmíyàn kú. Tó bá jé òtító ní Obàlùfòn Aláyémore tún wa joba léèkejì ní Ilé-Ifè a jé pé àsìkò Aláàfin Àjàkáló je oba.
Awon òtìtó kòòkan farahàn nínú ìtàn yìí. Lóòótó ni Obalùfòn Aláyémore kan wá ni Ilé-Ifè. Títí dí oní ògbón Obàlùfòn wa ní Ilé-Ifè. Àdúgbò Aláayè si wa ní Ilé-Ifè títí dí òní. Kò sí iró níbè pé Èfòn Aláayè bá Ilé-Ifè tan. Nínú ìtàn mìíràn, a gbo pé àwon orísìí ènìyàn bí i méfà ni wón tèdó lásìkò òtòòtò sí Èfòn-Aláayè. Nínú ìtàn yìí, a gbó pé Èkúwì ló kókó dé sílùú Èfòn-Aláayè, igbó-àbá ni Èkúwì tèdó sí. Ode kan tí orúko rè ń jé Oríkin náà tèdó sí Igbó àayè. Lójó kan, lásìkò tí oríkin tèdó, ó rí iná tó ń rú ni Igbó-Àbá. Ó se òde lo sí igbó yìí. Oríkin ro àwon tó wa ni Igbó àbá kí won jo má gbé ní Igbó-Àayè. Wón gbà béè. Lásìkò tí won jo ń gbé ni won fí Obàlùfòn je oba. Igbákejì Obàlùfòn tí wón jo wá láti Ilé-Ifè ní won fi je igbákejì oba tí a mò sí Obańlá. Bàbá Igbó Àbá ojósí ni won fi je baba olójà tí a mo sí Obalójà. Obàlùfòn àti Obalójà jé òré tímótímó nígbà náà. Bí oba se ń pàse fún àayè ní Obalójà se n pàse ní Òbàlú láyé ìgbà náà. Lónìí, Obalójà je Olóyè pàtàkì ní ìlú Èfòn. Obalójù ní olórí àwon Òbàlú. Àjose wá láàrìn Oba àti Obalójà. Bí oba kan bá wàjà ní ìlú Èfòn-Aláayè, iwájú ilé oba-olója ni won yóò kó ojà lo.
Nínú ìtàn mìíran a gbó pé ààfin Odùduwà ni wón bí Aláayè sí. Òkan nínú àwon omo-oba obinrin ló bii. O jé arewà okùnrin ti ènìyàn púpò féràn rè pàápàá àwon babaláwo tó ń wá sí ààfin. Ìtàn yìí tèsíwájú pé okùnrin yìí ní aáwò ni ààfin, èyí ló mú kí Odùduwà se fún Aláayè ní ilè sí ìráyè tí a mò sì Modákéké lónìí. Odùduwà fún un ni adé tó sì n jé Oba Láayè. Nínú ìtèsìwájú, Ìtàn mìíràn tó fara jo ìtàn òkè yìí, a gbó pé àwon omooba méjì ló fé lo te ìlú dó. Bó ba rí béè á jé pé ìlú Èfòn tí wá kí Modákéké tó dáyé. Àtàdá ati Johnson tilè maa ń to Aré àti Èfòn tèlé ara won.
Ni pàtàkì, ogun kò según Èfò Aláayè rí àyàfi Ogun Odérinlo (1852-54). Odérìnlo je omo Ìrágberí, béè ni Èfòn-Aláayè ni ìrágberí ti kúrò. A le so pe omo bíbi Èfòn ló kó Èfòn-Aláayè kì í se òtá nítorí òkè to yí wón ká je ìrànlówó púpò fún ìlú Èfòn-Aláayè, ó sì je wàhálà fun òtá. Àwon òtá to fe jà won lógun nígbó Òòyè, won se lásán ni. Ogun yìí fà á ti Aláayè kì í fi je osun ògògó titi dòní. Ohun àrífàyo nínú ìtàn yìí nip é ode ló te ìlú Èfòn dó gégé bí àwon ìlú mìíran ni ilè Yorùbá. Léyìn rè ni àwon mìíràn ń tèlé e wá sí ibi ìtèdó. Ó se é se béè nitori ibi ti ode máa ń tèdó sí kò ní jìnnà sí omit i ń sàn; àtipé yóò ti kó àwon eran rè jo sí ojú ibi ìdáná. Oja ló séyo láti ibè. A tún rí i pé eni tó je oba Èfòn gbé adé rè wá láti Ilé-Ifè; sùgbón àsìkò tó dé sí ibùdó yìí ni a kò mò. Lóòótó, eni tó bá jé alágbára láyé àtijo, tó sì ní àmúye ni won fi i joba, léyìn ti Ifá bá ti fore. Kò yá wá lénu pé wón fi eni tí adé ń be lówó rè je oba nítorí àwon ohun àmúye oba wà ni sàkání rè.
Ní ìparí, Finnegan (1970:368) so nínú oro re pé: …they (myths) depict the deeds of human rather then supernatural heroes and deal with or allude to, events such as migrations, war, or the establishment of ruling dynasties.
Èyí ni pé ìtàn ìwásè jé ohun tí ó selè ti pé, ó ń so nípa ènìyàn akoni àti awon nnkan to yi i ka bí ìrìnàjò láti ibi kan sí èkejì, ogun jíjà ati bí won se te ìlú dó. Encyclopaedia Britanica (1960:54) sàlàyé pé ìtàn ìwásè jé ìtàn nípa àsà tí ó ń sàlàyé nípa ènìyàn, eranko, òrìsà àti èmí àìrí. Irú ìtàn yìí kì í so àkókò gan-an tí ìsèlè sé sùgbón won jé kí ìtàn ní kókó àti ìsèlè tí a kò lò rí nínú ìtàn lásán. Ìtàn ìwásè máa ń je ònà kan pàtàkì láti sàlàyé ìgbé ayé tó ti kojá. Ò máa ń so nípa bí àwon ènìyàn se dé sí ilè kan ati ìdí tí àwon kan fi je gàba lórí àwon egbé rè. Volume Library (267) tilè so pé o ye kí ìgbàgbó wa rò mó ìtàn ìwásè nítorí ó jé mó àsà bí o tile jé pé kò sí eni tó mo ìbèrè ìtàn béè sùgbón ohun ti a mò nip é ìtàn ìwásè ti wáyé lásìkò tó ti pé.
A kò lè fówó ró ìtàn ìwásè ìlí Èfòn-Alàayè séyìn, bí ó tilè jé pé nínú àwon ìtàn tí àwon òpìtàn so fún wa, ìdásoró okùn-ìtàn wà níbè sùgbón nnkan tó se pàtàkì ní pé eni tó te ìlú Èfòn Alàayè dó wá láti Ilé-Ifè ní àsìkò ìgbà kan tí a kò mò. Ìlú ibi ti wón tèdó sí tù won lára, wón sì ń gbé ibè títí dí òní.
Àkíyèsí: A yo isé yìí láti inú àpilèko fún Oyè Émeè I.A. Ologunleko.