Iwe Akonilede Ijinle Yoruba 1
From Wikipedia
Akonilede Ijinle Yoruba
Adebisi Aromolaran Oyebamiji Mustapha (1976), Akómolédè Ìjìnlè Yorùbá Lagos Macmillan Nigeria Publishers Ltd. Ojú-ìwé = 15.
ÒRÒ ÌSAÁJÚ
Méta ni a pín òwó ìwé yìí sí, eléyìí sì ni àkókó nínú won. Èrò wa, gege bi olùkó akónilédè Yoruba ati olùdánniwò ni pé ìwé náà yóò wúlò fún awon akékòó ní ilé-èkó gíga ti Girama ati ilé èkósé olùkóni. Bákan náà, ìwé yìí yóò jé kòseémánìí fún awon tí ńgbaradì fún ìdánwò G.C. E. nínú èdè Yorùbá.
A ti se àkíyèsí wí pé kò tíì sí ìwé tí ó se àlàyé àsà ìbínibí pelu gírámà èdè Yorùbá gege bi ati se le ko ó ní òde-òní yékéyéké tó béè, ní àrówótó àwon olùkó ati akékòó. A se àgbéyèwò orisirisi èka òrò Yorùbá l’óríkèé ní èdè Yorùbá pón-m-bélé ní ònà ìròrùn tí ó le yé akékòó. Béè sì ni a wo ìsesí àwon òrò Yorùbá ati isé tí wón le se nínú gbólóhùn, ní onírúurú, láìfi ara èdè àwon ènìyàn tabi ìran mìíràn.
Èyí nìkan kó; a tún se àsàrò lori àwon àsà wa lati ìgbà ìwásè títí di òní olónìí. A rí i wí pé a kò le pé ayé di ayé òlàjú kí á wá kùnà lati bu olá fún àwon àsà ìbínibí tí àwon baba-ńlá wa fi nse gbajúmò lati ojó láéláé wá. Ìdí rèé tí a fi jíròrò nínú ìwé yìí lori àwon àsà wa bi mélòó kan laì ní àbùlà. Ònà kan nìyí tí a le gbà gbé ògo orílè-èdè wa ga.