Owo Eje ni Soki
From Wikipedia
ÌTÀN INÚ OWÓ ÈJÈ ti Kola Akinlade NÍ SÓKÍ
Yorùbá bò wón ní “ojú la rí, òré ò dénú” Ìfé tí a sì fé adìe kò dénú, kò ju ibi kí akó o ní eyin je lo. Ó se é se kí ó jé pé ojú òwe òkè yìí ni Akínlàdé mú wo àwon ìsèlè àwùjo - Yorùbá, èyí tí ó wá bí itàn àròso Owó Èjè tí ó ko ní gbèyìn-gbèyín ìgbésùnrawo àwùjo rè.
Ìtàn inú ìwé yìí dale orí àwon ìwà òdaràn tí à bá lówó tolórí-telémù èdá àwùjo. Bí ó tílè jé pé – Súlè ài Bísí jé olólùfé méjì tí wón pinnu làti fé ara won sílé gégé bí tokotaya; ikú Súlè ni kò jé kí wón lè mú àlá won se. Bísí ń sisé omo òdò lódò Àlàké nígbà tí Súlè àti Jímóò: èkejì rè jé ìgbìrà tí wón wá sí ilè Ondó gégé bí àtìpó. Àwon méjéèjì ń gbépò nínú ilé ti Bàbá Wálé fún won
Baba Wálé tí ó jé olórí àti omo onílè ní Abúlé ajé tí wón tún ń pè ni Súàrá Owóyemi fún òpòlopò ènìyàn abúlé ajé ní ilè tí wón fi dáko. Oko Bàbá wálé fúnra rè, enú-kòròyin ni. Olówo ni. Òun ni ó sì fún Súlè ní ilè tí ó fi dáko ní Abúlé Ajé. Lórénsì Awólànà tí ìnágije rè ń jé “Élíeèlì” tí ó ti fi ìgbà kan pa okùnrin kan tí orúko rè, ń jé Mósè Odúnewu ní Musin pèlú òbe, tí ó sì sá wá sí Ondo ni Baba Wálé fé gbà bíi dérébà okò tí ó sèsè fé rà.
Bákan náà, òpòlopò wàhálà ni Ògúndìran tí ìnagije rè ń jé ‘Ekùn tí se láti fé Bísí sùgbón pàbó ni ó ń yorí sí. Kódà ó be Àjíké egbón Bísí pèlú owó sùgbón Súlè Ìgbirà ni okàn Bísí fàmó pátápátá.
Sé awofélé bonú, kò jé kí á rí ikùn asebi ni òrò Bàbá Wálé tó gba Súlè àti Jímò sí ilé rè. Bí ó tilè jé pé àkísà ni Súlè wò dé abúlé Ajé sùgbón tí inú ire Bába Wálé so Súlè di ènìyàn, àse ohun tí Baba Wálé yóò se ń be nínú rè. Baba Wálé fún Súlè ní emu onímájèlé mu nínú ilé e rè Bàba Wálé pàápàá mu nínú emu yìí sùgbón ó dógbón lo aporó sí tirè léyìn-ò-reyìn nílé ìgbònsè. Ó sì bi emu tí ó mu yìí sùgbón Súlè kò rí aporó lò sí májèlé tí ó je láìmò yìí. Lójó náà ni Súlè kú. Nibe bákan náà ni Olóyè Olówójeunjéjé ti fún Súlè, Joséfù, Bàbá Wálé àti ‘Lànà ní obì je, béè gégé ni Lànà fún Súlè ní sìgá mu sùgbón Jóséèfù ní òun kì í mu sìgá.
Wàyí o, wàhálà dé, Bísí ń japoró ogbé tí àwon ènìyàn ìká sá a nítorí pé ó mò pé ènìyàn kan ni ó sekú pa Súlè Ìgbìrà tí ó jé olólùfé òun. Ó pe àkíyèsí àwon òtelèmúyé sí ohun gbogbo tó selè lórí òrò ikú Súlè. Ó sì fé kì Akin Olúsínà àti Túndé Atopinpin bá òun mú òdaràn náà tí ó pa Súlè.
Àwon agbófinró àti àwon òtelèmúyé bèrè isé ìwádìí nípa ikú Súlè. Wón fi òrò wà Àjíké lénu wò, àti àwon tí òrò náà ló mó lésè bíi Jóséèfù, Lànà, Ògúndìran, Jímò, àti Bàba Wálé gan-an tí ó jé òdádá. Ní gbèyìn-gbéyín pèlú òpòlopò akitiyan àwon òtelèmúyé-Akin àti Túndé ní ojà Olórunsògo níbi tí wón ti ń mu emu, òrò tí wón fi etí kó ràn wón lówó púpò, èyí tí ó sì fi Baba Wálé hàn kedere gégé bí eni tí ó pa Súlè nítorí àtijogún oko kòkó Súlè. Sàngbà fó, “aféfé fé, a ti rídìí adìe” owó te Bàbá Olówó Èjè.