Asa Yoruba III

From Wikipedia

TIAMIYU ADAMO GBADEBO


ÀSÀ YORÙBÁ


Yorùbá jé òkan nínú àwon èyà tí lajú jù lódé ayé yìí. Láti ìgbà tí aláyé ti dáyé ni wón tí ní ètò àti ìlànà nípa ohun gbogbo tí wón ńse ní ìgbési-ayé won. Bí-o-tilè jépé kò sí àkosílè àwon ètò àti ìlànà wònyí, gbogbo won ni àwon Yorùbá mò tí wón sí ńlò lójóojúmó títí ó fid i bárakú tàbí àsà fún won. Ara àwon àsà náà nìyìí: Ìkínì àti ìjéni, ìdèyún ati ìgbèbí, ìkómo àti ìsomolórúko, ìranraenilówò, ìsìnkú àti ogún jíjà àti oge síse.

Ètò tún wà fún ìjoba síse, isé síse, isé kíkó, ogun jíjà, ìjà lílà, ebí síse àti adura síse. Mímò àti tílèlé àwon àsà àti ètò ìbílè Yorùbá nínú ohun gbogbo se pàtàkì púpò láàrin won. Eni tí ó mo àwon àsà àti ètò wònyí ni a ńpè ní omolúàbí àti ologbón. Eniti kò bá mò wón ni a ńpè ni òbùn, òmùgò tàbí asìwèrè.

Gégé bí ati sàlàyé soke, òké àimoye nì àsà àti ètò Yorùbá sùgbón fún ànfààní àpílèko yìí, àwon méjì ni a máa gbé yèwò níbè. Àwon méjì yìí náà ni: Ètò ebí nílè Yorùbá, àti Ìwà omolúàbí.

ÈTO EBÍ NÍ ILÉ YORÙBÁ

Ebi ni baba, ìyá ègbón àti àwo ìbátan. Lónà kíní a ní láti mò wípé ebí se pàtàkì. Yorùbá sì jé òkan pàtàkì làra èyà tí ó wà láyé tàbí ní ilè Afíríkà tó jé pé àwon nìkan ló ni nnkan tí wón ńpè ní Òkè Ìpònrí. Nínú Òkè ìpònrí yìí ni ebí ti ńjáde wá. Bí òrò bá lé koko bí ojú eja, tí àwon ènìyàn bá so pé “má bínú mo fi alájobí bè ó”, tó bá jé omo Yorùbá yóò fi òrò náà síle.

Àjobí náà ni ńjé baba, ní í jé ègbón, nì í jé àbúrò ní í jé ìbátan ní í jé ìyekan. Ó se pàtàkì pùpò tó béè gé tí ó fi yà tó sí ti àwon Òyinbó tí wón ńpè ní ‘Family’. Yorùbá máa ńtan ebí títí yóò, fi so òpòlopò ènìyàn pò. Àwon Yorùbá gba ìyá àti baba bìi ìgbà tí ènìyàn gba Olórun ni; nítorí Ifá ní ńse Amònà won. Odù Ìfá kán so pé:

Òkún kún nàrenàre

Òsà kún lègbelègbe

Alásé ńrase

Alásè ńràsè

Àgbàlagbà ímàle wò gbèhìn òrò

Títí, ó gbòndíí rè pépépé

Ó dífá fún ìsèse tí i solórí

Orò lálè Ifè.

Baba eni ìsèse eni, Iyé, eni

Ìsèsè eni, orí eni ìsèsè eni.

Kí là bá bo kà tó bòrìsà

Ìsèse là bá bo, ká tó bòrìsà?

Ìsès là bá bo.


Ifá ni kí o tó bo Sàngó, kó o tó b’Oya, kó o tó b’Èlúkú, kó o tó b’Òsósì, kó o tó bo Yemoja, kó ó tó b’Ògún, kó o tó bomolè, ó ní, ìsèse ni kí o kó bo. Kó o bo baba, kó o bo ìyáà re. Àwon Yorùbá gba pé Òké ìpónrí ní baba àti ìyá jé.

Nínú ebí, enìkan kì í dálé kó kó dá a gbé, agbo ilé ni àwon Yorùbá máa ńgbé. Gbogbo ebí ni yóò jo máa gbé inú ilé kan náà. Omo inú ilé pàápàá tó bá jé obìnrin tó bá lo sì ilé oko tí ilé oko kò gbà á, tí ó padà wá sínú ilé-won ni wón ńpè ní omo osú.

Nínú ilé, nígbà tí ènìyàn bá pò, olórí yóó wà. Yorùbá kìí fi òrò àgbà seré. A ti ńje Olórí ní ilè Yorùbá kó tó di pé àwon Òyìnbó dé. Eni tó bá jé àgbàlagbà jùlo nínú ilé ni í je “baálé”. Bí oyè bà sì kan àgbo ilé náà, eni tí ó jé àgbàlagbà jùlo ni wón fi í je é. Sùgbón nísisiyì, owó ni àwon ènìyàn-an wá ńfí se é, Òwo loyè. Èyí burú púpò, àwon baba wa kì í se béè. Àwon baba wa máa ńse e bí won tí ńse é. òun ni í jé kó rí bó ti ńrí. Bí olórí ilé kan bá sí kú, kì í se àrèmo rè ni yíò tún je baálè, eni tó bá tún dàgbà jùlo ni wón fí ńjé é. Bí irú eni béè bá di baálé tán áwon ìyókù yóò máa se sí i bí òun náà ti se hùwà sí baálé ìsáájú. Bí òrò kan bá sì délè àwon àgbà ni won máa ńso ó nítorí náà ni won fi ńso pé ‘àse mbé lénu àwon àgbà’.

Kò sí Baálé tí ó ńfé ki ilé tú mó òun lórí, nítorí irú eni béè kò ní fé kí wón pa ìtàn buburú nípa òun, nítorí Yorùbá féràn ìtàn púpò. Bí o ba fi ìtàn bú Yorùbá, wón kì í dárí ji ni. Òrò a máa dùn Yorùbá. Yorùbá kì í sìí fé se nnkan ìwòsí tàbí je oúnje iwòsí nítorí ìtàn pípa.

Bí ti baálé ilé náà ni ti àwon obìnrin ilé, Olórí àwon obìnrin ilé ni wón ńpè ní “Iyáa káa” èyí si ni eni tí ó jè àgbàlagbà obìnrin jùlo, òun ni yíò parí ìjà tábì aàwò tó bá sùyo láàrin àwon obìnrin ilé. Ní ayé òde òní, ó dàbí enipé ebí tí ńyá, sùgbón bó ti ya tó, nnkan tí won fí ńsebí ó ye kí à sì máa lò ó. Kí a fi orí fún eni tí orí ńse tirè. Òrúnmìlà ní:

Olórí ni à ńforí fún

A dífá fún èrinméjo irúnmalè

Níjó ti wón ńrelé Olódùarè lo sodún.

Eni tí o bá jé Olórí, a ní láti fí orí fun un.

Béè náà ní ètò ti omo ìyá, gbogbo èyí ni àwon baba wa ti tò. Wón gbà pé gbogbo eni tó bá ti saájú eni dáyé ju ni lo, a sì níláti máa bu òwò fún won. A kò sì gbódò yájú sí won nítorí, “Ení bá fé dàgbà kò gbódò gbòpá lówó arúgbó”. Enikéni tó bá ju ni lo, ìdòbálè ni wón máa ńki wón, bí wón bá tí je mòlébí. Gbogbo ètò wonyi máa ńmú kí ilé gún ni. Fún àpèère, bí enikan bá fé fi omo fóko, olórí ilé ni ó ni ètò à ti fi fún un, nítorí wón ńfé kí gbogbo ilé lówò si ohunkóhun tí ó bá tibè súyò. Àwon àgbà wònyí ló sì máa ńfàse sí ohun gbogbo, bó jé ìjà ni, àwón ni yóò paríi rè. Olórí ilé yì lé sàìlówó, sùgbón ní ti ojó orí, òun ni yíò se olórí.

Orogún ní ètò tí àwon baba wá ti fi lélè fún won. Sùgbón àwon obìnrin iwòyí kò se é bí won tí í se é, òun ni kò jé kó rí bi í tí í rí. Èkíní, ìyàwò àkógbé kò sé é, fí seré lówó àwon baba wa. Ìyàwó àkógbé ni àwon baba wa máa ńsètò ohun gbogbo fún, àwon ni wón máa ńsorò gbogbo fún títí dára bí oko bá se fé soorun, gbogbo èyí ni ìyàwó àkógbé tàbí ìyàálé yì yóò mò pátá. Ìyàálé yí sì máa ńfún omo orogún lómú, sùgbón àwon tòde òní kò le è sé é rárá. Èyí sì máa ńmú àwon orogún se bí omo ìyá. Eni tí ó bá so pé Yorùbá kò mètò, iró ńlá ni, àfi bí won kò bá fé se é. Gbogbo ètò bí a ti ńse ìbátan ni àwon baba wa ti fi lélè. Àwon baba a máa kìlò fún àwon omo wón ohun tí wón kò fé kí wón se bí-ó-tilè-jépé ààrin ìbátan kan ni.

Òrúnmìlà so pé:

Bí omodé bá fé hùwà ògbójú

Tó bá ri ògbó awo kó gbá a lójú

Bí ó bá ri àgbà òsègùn kó je é níyà

Bí ó ba ri aáfàa níbi tó gbé ńforí balè fún Olórun,

Kó dojúu re délè

Á dífá fún àwíigbó

Omo tó ńlùgbó awo

Tí ńjà gbà sègùn níyà

Ó rí alùfáà níbi tó gbé nkirun

Ó dójú è dé lè

Òrúnmìlà ní kí e fi sílè, Ó wá fi yé won pé:-

Àjepé ayé kò sí fomo tó lùgbó awo

Àtelèpé ò sí fomo tó lùgbà òsègùn

Omo tó dojú àfáà délè níbi tó gbé ńyin Olórun Oba

Owó ara rè ló fí ńwákú

Wàràwàrà nikú ìdin, wàràwàrà.


Oríkì a máa fi ebí hàn, a máa mbí àbíjo. Won a máa pa ìtàn fún ni pé ‘báyi ní eléyì rí. Òmíràn wà láàrin àwon ebi nígbà tí ilé bá kan ilé bayí, tí òré bá wo ara won nínú mòlébí, wón a dòré wón a dìyekan. Àwon Yorùbá ìjelo, bí òré bá pò ti òré bá wonúara wón títí, won kì í fé ara wón. Wón rò pé ó ti di mòlébí. Nítorí pé wón féràn ara wón púpò, wón wá di pé mòdàrú dé, ilú míràn wà ní ilú òkè, tí a ó rì olópa mérin péré ní bè. Fún àpeere, nígbà tí mo wá ní Ògbómòsó-ìlú keta tó férè tóbi jù ní Nàìjíríà-ní nnkan bí i 1930-Olópá tí ó wà ní ìlú náà kò ju mérin lo. Ilé èwòn, etí Òsogbo ló wà. Ìdí ni pé wón mo ètó. Ewúré á wà níta, bó o sáso kò s’éni tí ó ká a, ká to wá pé enìkan mú ìbon lówó. Bí ijà dé wón ó paríi rè nínú ilé. Bí won kò paríi rè nínú ilé, wón ó lo òdòo Baálé àdúgbò. Bó bá dè òdò alàgbà a jé pé olúwa rè dáràn nìyen. Bí a bá gbó pé onísé baálè ńpè ènìyàn elòmíràn a sá gún òkè àjà. Àwon elòmíràn so pé ìjoba yìí kò mú ìlosíwájú lówó. Sùgbón kí á so pé owó tí ìjoba òde òní ńlò lórí olópá, tó bá jé pé wón fi se omi sí Èkó ni gbogbo wa ni ìbá máa rómi mu. Bí wón bá fo ńtanná ni, yóò dé ìlú òkè. Nítorínáà àwon baba wa ní ètò tó dára púpò. Eléyí ló jé kí wón lé gbé ayé bí a tí ńgbé ayé. Àwon baba da ara wa. Ká sòtító. Ká pón ara wa lé. Ká kó ara wa ní ìjánu. Òrúnmìlà ní:

Ìwòrí tejú móhùn ti ńseni

Bá a bá tè ó nífá tán

Kó o tún raà rè tè

Ìwòrì tejú móhun ti nseni

Awon má féjà igbà gun òpè”.

Mó pé ńtorí pé o ti sawó kó o fi igbà tó ti já tán gun òpè.

Ìwòrì tejú móhùnto ńseni

Awo mó fibínú yòbe”

Ìjà kì í dé kórò gún ra won káwo wólé yòbe

Ìwòrí tejú mo hunt i ńseni

Káwo mó sán bànté Awo.


Itumòo rè ni pé, e má bá araa yín lóbìnrin sùn. Iyàwó Awo ni ibànté Awo. Won ní olúwa eni kì í bíní léèrè òrò ká sé. Bá a bí ó léèrè òrò so òtító. O ò gbódò sàsèjù nípòkípò tó o lè wà. Má se rá omo ènìyàn je.

Ká má fi kánjúkánjú jayé,

Ká má fi wàràwàrà jákùn idà

Òrò tá a bá fi sà gbà, kámá fi se bínú

Tá a bá débi tó tutu

Ká sinmi sinmi

Òrúnnmìlà ní ká wo wájú ojó títí títí

Ká wèhìn òràn sun un

Nítórí àti sùn eni


“Ati sùn” ni pé, nítorí ojó ìkéhìn. Torí Yorùbá a máa ran ‘ró. Bí Yorùbá kò bá ran’ró kò ì tí ì ráyè ni; nítorí wón so pé:

Bí owó omodé kò bá te eèkù idà

Kì í beèrè ikú tó pa babaa rè.

Wón ní àkódá oró kò dàbí àdágbèhìn. Nítorí èsan ni Yorùbá se máa ńsa fún láìfi araa wón. Yorùbá kì í ja ìjà èbi.

Eke síse kò pé á mò lówó lówó

Ilè dídà kò pé á mò dàgbà

Ojó atisún lebo.

Eléyìí jé ètò Ebí àwon Yorùbá.

ÌWÀ OMÓLÚÀBÍ

Lóde òni, ó dàbí eni pé gbogbo ohun mèremère àti ohun èsó tó ńtún orílè èdè se wón ju ti àtijó lo. Ñnkan abàmì, ñnkan abànìyànlérù ni a sì ńgbó nígbà gbogbo. Emi kò fé kí e rò pé kìkì ohun ìbèrù yìí nìkan ló wà nílèe wa, ohun rere náà wà níbè. Sùgbón ohun tí mo fé tenu mó ni pé nígbà tí ìwà omolúàbí bá ti ńdinkù ní orílè-èdè, ìwà buburú, ìwà abàmì tí kò bójú mu yìí ni ó sábà ńgorí ìwà rere àti ìwà omolúàbí.

À ńgbó nípa olè, à ńgbó nípa kólékólé à ńgbó nípa dánàdanà, à ńgbón nípa gúnbegúnbe, à ńgbo nípa àwon jàndùkú, à ńgbó nípa ayolé ayo-òde-lénu. Njé gbogbo ìwònyí dára láti wà láàrin orílè èdèe wa bí? Kí ó tó di pé a dáhùn ìbéèrè yen a lè so pé, lénu ìgbà ti ojú wa dá yìí, ó dàbí eni pé ayé dára jú eléyì lo. Ó dàbí eni pé ènìyàn lè gbé ñnkan rè síwájú ahéré rè kó sì bá a níbè, o dàbí eni pé obìnrin lè lo ségi lóko kó pa àlà lé e lórí tàbí kó pa ààlè lé e lórí kó sì bá a níbè. Sùgbón láyé ìsinsìnyí, èyí tí ènìyàn ló gbà pé bí owó bá wà nínú ilé ìfowópamósí kò sí ohun tó lè se irú owó béè. Ayé àtijó ni a ti ńso pé a kì í fi ojú bòrò gbomo lówó èkùró. Ó ti wá di pé àtomo èkùró ni o, àti èkùró ni o, ojú líle àti ojú bòrò, gbogbo rè la ńpapò láti gbomo lówóo won. Ohun tí mo ńtoka sí nísìnyí ni pé ìwà omolúàbí dàbí enipé ó ńdín kú díèdíè. Béè ni láyé àtijó iyì ńláńla ni láti pe enìkéni ni omolúàbí. Àlàyé omolúàbí yíì ni mo fe kó yé wà kedere. Kì í se eni tó bá lowo lówó nìkan soso la ńpé lomolúàbí. Kì í se òjògbón, kì í se gbajúmò. Nílè ‘E káàárò e ò jí i re’ wa yí, eni ti a ba pè lómolúàbí ni eni ti ó kó gbogbo ìwà rere pò, ti o sì jé eni tí elégbé àti ojùgbà kà sí ojúlówó ènìyàn. O dá mi lójú, ó sì dá àwon ará ilè Yorùbá lojú pé, ìwà rere, òun ni èsó ènìyàn. Àti pèlúpèlù pé orúko rere, gégé bí a se ńso o ni òwe ilèe wá, dára ju wúrà àti fàdákà lo. Nígbà tí mo ti so fún yín irú ènìyàn tí a lè pè lómolúàbí yìí, e lè fé máa tóka sí enìkan tí e bá mò pé a lè pe eni yí ní ómolúàbí. Ojúlówó omolúàbí sòwón; sùgbón síbèsíbè, à ńrí díèdíè lárá wa.

Omolúàbí ni eni tí ó sábà ńní ohùn rere lénu, torí pé ó mò dájúdájú pé òrò tí ènìyàn bá so lénu ló ńfi hàn bí okàn àti inúu rè ti ri. Gégé bí a se máa ńso lórò àwon àgbà pé, ‘Ohùn rere ló máa ńyo obì lápò’, ó sì tún dájú pé, ofà ni ohùn buburú ńfa jáde lápó!’Kàkà kí omolúàbí sòrò buburú lénu ó máa ńdáké ni. Èyí tí àwon ará òkèèré ńso pé; ìpa-enu-eni-mó ni àkójá òfin.’ Bó tilè jé pé omolúàbí mo ìgbà tí ó ye kí ó máa dáké, bákan náà ló sì mo ìgbà tí ó ye kí o máa la enu rè. Nítorí pé, omolúàbí a máa kí ènìyàn pèlú ìyési àti òwò. Kò séni tó so fún omolúàbí pé, ‘eni tí kò kí ni kú ilé, o pàdánù e kú abò,’ nítorí pé ó mò dájúdájú pé bí òun ò bá ti kí ará ilé kú ilé, sírisírí ni àwon ará ilé ńse sí ni. Nítorí náà, ni àárò ni o, ni òsán ni o, ní alé ni o, seni omolúàbí máa ńyá mó ènìyàn, tó sì tún ńkí aládùgbò rè tinútinú, pèlú ìfé àti pèlú inú rere. Omolúàbí kì í yodì, kì í féèyàn sínú. Ó mò, ó sì dá a lójú, pé: érùu ‘hò’ kì í wo ènìyàn lórùn. Bákan náà ló sì tún fi sókàn gbákogbáko pé “eni tí kíkíi rè kò yóòyàn àìkíi rè kò lè pàni lébi”. Kò sì lè pani pàápàá. Nítorí ìdí èyí, ó máa ńjé kí òrò ìwúrí àti òrò ìyánilórí jáde lénu òun.

Kíkí tí omolúàbí ki í se irú èyí tí à ńfi èjè sínú tu itó fúnfun jáde lénu. Irú èyí tí ó ti oókan okan rè wá ni. Torí pé omolúàbí náà fúnra rè mò pé, ‘Akíni ńjé akíni, afinihàn ńjé afinihàn, èwó ni pèlé o ará Ìbàdàn lójúde Sódeké?’ Omolúàbí kò ní je kí kíkíi rè ni asò tàbí afinihàn nínú. Se a mò pé òrò tí ó bat i enu wa jáde ni a ó fi mò gégé bí inu se rí. Bákan náà omolúàbí a máa gba òrò aládúgbò àti ojúlùmò àti àwon elòmíràn béèbéè yèwò. Bí elòmíran bá wá ní ìsòro, omolúàbí yíò gbìyànjú láti mú ìsòro rè kúrò tàbí dín in kù. Láìsiyè méjì, omolúàbí mò kedere pé, ‘bí ará ilé eni bá ńje kòkòrò buburú, bí a kò bá tètè so fún un, hèrèhuru rè kò ní jé kí á sùn lóru.’ Nítorí náà ńkó, omolúàbí kì í fi iná sí orí ilé kó lo sùn sábée rè.

Síbèsíbè, bí omolúàbí bá ti ńse òrò ni ó máa ńfi ogbón se è tó béè géé tó jé pé kì í sábàa ré kojá aye rè. Èyí ni pé kì í se àsejù tàbí, lórò míràn ńkó, omolúàbí ènìyàn kò gbódò ti ojú eni tí ó bá ní ika mésán kà á. Omolúàbí a máa lo ogbón orí ará rè láti fi se àwon ñnkan jànkanjànkàn tí ó tó sí i láti se sùgbón a máa se é pèlú ìrèlè. Kò di ìgbà tí àwon ènìyàn bá ńse àfojútóo rè, kò di ìgbà tí ó bá ńsisé lábé ààbò àwon elòmíràn kí ó tó máa tún omolúàbí rè se. Ó máa ńse ojúse rè ni, bó tilè jé pé ènìyàn wa níbè tàbí kò sí níbè. Omolúàbí máa ńfi kíkí se òrò àwon òjògbóm pe bí a bá rán ènìyàn nísé erú a ó fi jé tomo. Ju gbogbo rè lo, omolúàbí ènìyàn mò, ó sì ńhàn ni ìsesíi rè pé, èhìn ni ogbón ti ńwá. Gbogbo omolúàbí ló ńgbédí sókè fún òrò tí àwon àgbàlgbà sáabà ńso pé “ogbón ológbón kì í jé kí á pe àgbàlàgbá ní wèrè.” Ìdí pàtàkì tí omolúàbí fi ńfi oókan àyàà rè gba ìmòràn láti àsìkò dé àsìkò nìyí. Omolúàbí a máa jé kí ogbón bá òun gbé nígbà gbogbo, a sì máa fa ènìyàn móra.

Mo rò pé mo ti so nísájú pé omolúàbí kì í lodì, sùgbón, e jé kí n se àfikún òrò náà dájú báyí pé, bí enikéni bá sè omolúàbí yóò rántí pé, ‘sè mí n bí é ni oògùn òré, Ñnkantó jé ki n fa òrò yí jáde ni pé, bí a bá so pé èhìn ni ogbón ti ńwá, ti omolúàbí ènìyàn sì fé gba ogbón náà ńkó? O lè máa tì torí ìrékojá àwon tó ti èyìn rè wa, kó fé máa ko èhìn sí òrò ogbón. Èyí ni pé ti a ba pé ènìyàn ní Kòfésò, tó bá sì je pé Olùkóni wà lábée rè tó so pé alàgbà “Òrò té e só yen kò bójú mu o”. tó bá fé jéni tí kò fé sò ni, ó máa gba òrò yen yèwò. Èyí ni pé ó ni láti mò lésèkésè pé eni ti ó sòrò latièhìn wá yen tún wa ní ipò láti rí òrò náà ni kodòro ju òun lo. Omolúàbí a máa dúró si àyè rè nígbà gbogbo, òun náà ni mo ti só nísàájú pé kì í sègbà gbogbo ló ńkojá ípòo rè. Ó mò pé ‘ilé ni mo ńgbé kì í jèbi ejó! sùgbón síbèsíbè ó ní láti máa yojú sí òrò nígbà tí ó bá ye kí ó se béè. Àkókò fún ará rè ni ó sáab’`a máa ńsàpèjúwe ohun tí ó ye kí omolúàbí se. Bí omolúàbí bá ti ńdàgbà sí i, bákan náà ló ní láti máa rántí pé òun ní láti máa kùgbé òrò tí ó ye kí òun se nítorí pé ohun tí ó yé ológón ni pé “à gbà kì í wa lójà kí á jé kí orí omo tuntun wó.” Èyí ni pé bí omolúábí ènìyàn bá ti ntóbi si ní ìbùgée rè, ní ìlúu rè, ní orílè èdèe rè lo ni láti máa gbà pé isé àti ètò ti wón ni láti máa se sí sàkání òun ní láti máa pò sí ju ti àtèhìnwá lo. Kì í se àwon ti o ba tobi julo nìkan soso ni omolúàbí ní láti máa bòwò fún. Bí ó bá ti ńbu olá fún àgbà ni yóò tún máa se fún àwon omodé nítorí pé òun náà ti mò pé, ‘bí omodé bá ti mò owó ó wè ó ní láti lè bá àgbà jeun.’ Jù gbogbo rè lo, omolúàbí ní láti máa fi sí okàn ará rè pé, ‘a kìíru eran erin lórí kí á máa fi esè tan ihò ìrè nílè.’ Èyí ni pé, ó ní láti gbà pé ayé òde òni tí a wá, ayé òpòlopò ènìyàn ni. Ó ní láti mo wí pé ‘je kí n je òun ló ńínú ayò ó dùn’. Ó ní láti mò pé bi eni méjì bá gun orí esin, dájudájú enìkan ní láti wà níwáju enìkan sì ní láti wà léhìn. Ó sì ní láti mò pé ìgbà tí owó òtún bá we òsì, tí òsì sì we òtún ni owó ńmó.

Nígbà gbogbo, níbi gbogbo ni omolúàbí ní láti jé kí á bá ìsesí tí ó yeni lówó òun àti lódò òun. Ohun tí ó bá ní láti mú ìfura wa ní láti jìnnà sí òdò omolúàbí. Omolúàbí kò gbódò bá oníwà buburú tàbí alárékéréké rìn pò, nítorí pé, ‘àgùtàn tí o bá ti bá ajá rin dandan ni ki ó je ìgbé’. Ó sì ni láti mò pé, ‘a kì í pe ni lólè ki a máa gbé omo eran seré’. Lórò kan ńkó, omolúàbí kò gbódò lówó si ñnkan tí ó lè ba omolúàbí rè jé. Kò gbódò sí ìwà pálapàla, àìsedéédéé, àgàbàgebè ni sàkání rè. Ohun pàtàkì tí omolúàbí ni láti rántí ni pé, ‘E jòwó, e gbà mí’, kò ye egúngún, ‘eranko ni ńle mi í bo’ kò ye ode. Èèwò ni gbogbo ohun wònyí. Omolúàbí kò gbódò jèèwò. Ìhùwasí omolúàbí ní láti bójú mu. Ìhùwàsí rè sì ní láti bó sí ohun tí àwon olódodo ènìyàn ńreti láti òdò rè. Ta ni kò mò pé, ‘àifenipeni àìfènìyànpènìyàn ni ńmú ará oko sán bànté wòlú’. Ká má ri, omolúàbí kò jé sán bànté wòlú. Ìgbésí ayé omolúàbí ni láti je àpeere ìtèsíwájú fún ànfààní ìlú rè àti orílè èdè rè.

Láyé ìgbàànì, èyí ni láyé àtijó, nígbà tí monááfìkí mo ní ìbá, tí ayé kò tí i lu jára, ògòòrò ènìyàn ló fé kí á ka àwon kún omolúàbí. Nísínsìnyí, àféjù ohun ayé, àsejù fàájí, àìlóue mípa ohun tí ó se kókó nígbesí ayé omo ènìyàn ti jé kí òpòlopò ènìyàn fi ìwa omolúàbí won sílè. Àwon mìíràn ti je kí àwon àsà ilè míran gba àwon àsà iyebíye ti ìsèdálèe wa nù.

Àwon mìírán rò pé òlàjú ni pé kí a ko èhìn sí àwon ohun tí ó jé tiwa láti ojó jojo séhìn. Ó jé ohun tó dun ní láti rí i pé a ní láti máa se àtunyèwò okàn wa láti rí i pé àwon ìhùwasí wòonnì tá a fi í mo omolúàbí. Sùgbón gégé bí gbobgo wa ti mò, ‘bí òwe bí òwe ni a ńlú ìlù ògìdìgbó, ológbón ni í jó o, òmòràn ní í mò ó’. Omolúàbí nìkan soso ni ó mò bí a ti ńjó ìlù ògìdìgbó òun ló sì ńmo ñnkan tí afi ńjó o, òun ló sì mo ìtumò orin rè.

Àwon olùkóni ni ipa ńlánlà láti sà nípa àti rí i pé omolúàbí pò ní ilèe wa. A lè so pé àpeere dára jù òfin lo. Nítorí ìdí èyí ni pe ó ye kí àwon olùkóni fi àpeere ìwà omolúàbí hàn ni ilé èkó, ní ilé ara won. ní ìlú won ati ni orílè èdè won Ònà kan soso náà ni yen torí pé bótilèjépé à ńfi àpeere yìí hàn nígbà gbogbo tó bá jé pé ohun tó yí wa ká pò jù wá lo tàbí tó bá jé pé, ó ni ìba tí àpeere wá lè hàn mo, a tún rí ònà mìíràn tí a lè fi fi ìwà omolúàbí han òpòlopò ènìyàn.

Ñnkan tí kò jé kí àwòn ènìyàn mò nípa ìwa omolúàbí ní ayé àtijó ni pé àkosílè wa kéré púpò. Tó bá yè ni àwon ñnkan tí a tè sí opón Ifá, ìba àkosílè díè ni a rí ní ilè Yorùbá. Ó lè jé pé ní ojó iwájú a tún lè gbé ilè kan àwon ìwé tí eèrà tàbí ikán kò tí ì je. Èyí ni tó bá jé orí òkúta ni won hán án sí a sì lè mò bóyá àwon ènìyàn wá ti ko àkosílè. Sùgbon láì sí àkosílè yí, mo fé é so ní ìparí òrò ni pé láàrin àwon omo ilè Yorùbá eni tó bá kó ògo já ni à ńpè ní omolúàbí. Omolúàbí yìí sì ní láti se é títí di ojó tó máa kó ògo yen já. Nítorí pé kì í se ojó yìí nìkan soso ni omolúàbí ńwò. Ó ńwo ehìn òla nítorí ó mò pé bí òsìkà ènìyàn bá kú rere, ó lè má sùn rere. Nítorí náà ńkó, omolúàbí a máà fé kí òun ó kú rere kí òun sì sùn rere.