Iwe Akonilede Ijinle Yoruba 2

From Wikipedia

Akonilede Ijinle Yoruba

Adebisi Aromolaran Oyebamiji Mustapha (1974), Akómolédè Ìjìnlè 2 Yorùbá Lagos Macmillan Nigeria Publishers Ltd. Ojú-ìwé = 164.

ÒRÒ ÌSAÁJÚ

Ìwé yìí jé èkejì ninú òwó ìwé Akómolédè Ìjìnlè Yorùbá tí a ko fún àwon akékòó ní ilé-èkó gíga Girama ati ti àwon olùkóni. Ìwé náà yóò tún wúlò fún àwon tí ó ńgbáradì fún ìdánwò G.C.E. Yorùbá ati àwon tí wón ní ìfé sí ìmò ati ìlosíwájú Yorùbá.

Àkòtun ni ìwé yìí tún jé gege bi ti ìsaájú rè Isé ìdárayá ati ìdánrawò wà fún akékòó ati olùkó, a sì fún àwon akékòó ati olùkó ní ànfààní lati jíròrò, ati lati ronú jinlè lori níwòn ìgbà tí bebe kò pin sile enìkóòkan. A ní èrò pé bí awon akékòó bá ti ńtèsíwájú nínú èkó wònyí ni awon olùkó won yóò maa túbò ràn wón lowo nípa ìwádìí ati ìjìnlè èrò tí wón tin í lori èkó kòòkan. Awon olùkó yóò túbò fi àbájáde èrò ati ìwádìí won kó awon akékòó ní ìlànà tí a ti se sile. Ònà yii ni a rò pé yóò fún awon akékòó ati olùkóni ní ìgbáfadì ati okun lati tèsíwájú nínú èdè Yorùbá.