Otito Sise

From Wikipedia

ÒTITÓ SÍSE NINU OSELU

Nínú orin àti ewì ajemósèlú láwùjo Yorùbá ni a ti máa n tepele mó ànfàní tó rò mó òótó síse. Bí àpeere olórin kan so pé:

Lílé: Sòtító, a ó sòtító

Sòtító oo, a ó sòdodo o

Bó tilè korò,

Òtító la ó so

Ègbè: sòtító, a ó sòtító…

Nínú ìgbésí ayé èdá yálà okùnrin ni tábí obìnrin, yálà omodé ni tàbí àgbà òtító síso se pàtàkì, Yorùbá bò wón ní “olóòtó kan kò ní kú sípò ìkà” nítorí pé eùi tí ó bá n so òtító bó tilè wù kí ay ay kórira rè tó, inú kan tí ó ni àti òtító tí ó n so yóò máa kó o yo lówó àwon ìkà ènìyàn. Òtító síso se pàtàkì láwùjo Yorùbá àti láàrin gbogbo ènìyàn lápapò nítorí pé ibi tí òtító bá wà yálà ibi isé tàbí ìlú tàbí orílè-èdè kan ìtèsíwájú, àseyorí, ìgbéga, gbogbo àwon nnkan wònyìí ni yóò máa joba níbè, nínú ohun gbogbo ni ó ti ye kí á máa se òtító, èyí ni ó mú kí àwon omo egbé olósèlú kan tí á mò sí egbé oníràwò (Alliance for Democracy) máa ko orin yìí ní àsìkò ìpolongo ìbò, orin náà lo báyìí:

Lílé: lékélèké legbé wa

lékélèké legbé wa

Àwa kì í segbé àparò

aláso pípón

lékélèké legbé wa

Ègbè: lékélèké legbé wa…

(Àsomó II, 0.I 174, No.1)

Eye ni lèkélèké jé, ó sì funfun báláú, tí a bá wá gbó orin yìí, èyí túmò sí pé àwon egbé eléye n so pé kò sí mògòmógó nínú ohun tí àwon yóò se nígbà tí àwon bá dépò tán. Ohun tí ó túmò sí náà ni wí pé òtító ni àwon yóò so. Àparò aláso pípón tí wón lò nínú orin yìí je àfiwé elélòó (metaphor) tí ó túmò sí àìsòtító láwùjo Yorùbá Ohun tí àwon egbé oníràwò (Alliance for Democracy) n so ni pé ènìyàn tí ó bá fi òtító lo ipò nígbà tí ó bá dé ibè, ó di dandan kí ayé kí ó san-án, ó sì di dandan kí àwon ènìyàn gbárùkù ti ìjoba rè, níwòn ìgbà tí ó bá ti lè se ohun tí àwon ìlú n fé. Olánréwájú Adépòjù tilè so nípa òtító sísó nínú ewì rè ti o pe àkolé rè ní òrò osèlú (1981) pé:

Dájúdájú iró ò lérè nínú

E jé ká mó-on sèlérí òdodo

Bá a bá sòrò tán ká fi sókàn

ló tónà

O ní won ó rí o lálè, wón retí

wón remú, won ò rí o lódún

O sèlérí ìrànlówó tán o yowó

kúrò nínú òrò

ìwo fi wón lókàn balè lásán,

o so won nírètì dòfo, só dá a?

O fìtìjú bá won kárùn tán

O wá gbàgbé òrò

O ò mò wí pe ba a ba n sèlérí

lásán a kì í níyì ni ndan?

iró pípa kiri ní í múni í

deni yepere

(Àsomó 1, 0.I 73, ìlà 330 – 344)


Bí a bá wo àwùjo Yorùbá lónìí iró ni ó gba ayé kan pàápàá lénu àwon olósèlú wa, nígbèyìn èté ni iró won yìí sí máa n yorí sí nítorí òtító síso lérè nínú púpò. Ìdí nìyí tí Yorùbá fi máa n so wí pé “puró n nìyí èté ní í mú wá”.