Orin Eebu
From Wikipedia
C.O. Odejobi
C.O. Odéjobí (1995), Ìhun Orin Èébú ní Ifè.’, Àpìlèko fún Oyè Émeè, DALL, OAU, Ifè Nigeria..
ÀSÀMÒ
Isé yìí se àtúpalè orin èébú ní ààrin àwon Ifè. Isé náà fi orin èébú hàn gégé bí òkan nínú àwon èyà lítírésò alohùn Yorùbá. Isé ìwádìí yìí se àfihàn ìhun àti orísirísi ònà ti àwon ènìyàn Ifè máa ń gbà se àmúlò rè. Tíórì ìfojú-ìhun-wo-isé ni a lò láti se àtúpalè ìhun àti ìlò àwon orin èébú tí a kó jo.
Isé yìí rí Ifè gégé bí èka-èdè Yorùbá kan.Nítorí náà isé yìí dé àwon ìlí tí ó ń so èka-èdè Ifè bíi Ilé-Ifè, Ifèétèdó pèlú Òkè-Igbó àti Ifèwàrà.
Ìhun orin èébú fi hàn pé orin kúkùkú tí kì í ju gbólóhùn ewì mérin tàbí márùn-ún ni orin èébú. Níbi tí a bá ti rí orin tí ó ji gbólóhun ewì márùn-ún lo, ó lè jé pé òkorin se àkotúnko gbólóhùn ewì márùn-ún àkókó ni.
Ohun mìíràn nip é àwítúnwí jé àbùdá pàtàkì fún orin èébú. Ó sì ń jé kí ètò ìwóhùn orin dógba. Ìwóhùn yìí máa ń mú kí òkorin fi ìjára-ìjásè kún orin rè, èyí tí yóò sì jé kí ó lè fi ohùn àti òrò orin rè dábírà nígbà tí ó bá ń se àwítúnwí yìí. Gbogbo èyí lápapò ni ó ń jé kí orin èébú jísé tí a rán an.
Ohun mìíràn tún ni pé àwon obìnrin ni òkorin èébú. Bí àgbàlagbà obìnrin se ń ko orin èébú béè náà ni àwon omodé ń ko ó. Àwon tí a máa ń dojú orin èébú ko sì le jé obìnrin tàbí okùnrin. Àwon òkorin máa ń fi orin èébú gbé èrò okàn won síta fún ayé gbó.
Àwon òkorin èébú tún máa ń lo orin èébú láti se àtúnse ìwà ìbàjé inú àwujo. Bákan náà ni wón tún ń lo orin náà lati fi wá ònà ti òpin yóò fid é bá aáwò láàrin ènìyàn méjì ní àwùjo.
Ní àkótán, isé yìí se àfikún ìmò àwon ènìyàn nípa ìhun àti ìlò orin Yorùbá ní pàtàkì jù lo orin èébú.
Ojú Ìwé: Eétàlélógósàn-án
Alámòjútó: Òmówé A. Akínyemí