O. Olutoye: O pegede
From Wikipedia
O. Olutoye
Adeboye Babalola
Babalola
O. Olútóyè (2000) (olóòtú), Ó Pegedé. Ikeja, Nigeria: Longman. ISBN: 978 1396385
Afolábí Olábímtán ni ó ni àpilèko àkókó. Bí àwon òsèfè se ń lo èdè won ni wón fè lójú nínú ìwádìí won. Nínú àpilèko yìí, Olábímtán se àlàyé lórí bí àwon òsèfè se máa ń fi èdè ìbà tu òrìsà nínú, tí wón ń fi èdè inú orin won ráwó sí àwon ìbo, tí wón ń fi tòwòtòwò bá oba àti ìjòyè wí, tí wón ń nu àgbà ìlú lórò láìyo èébú lára won. Olábímtán fi hàn wá pé òsèfè kó ni ó ń dá orin rè kó jo-gbogbo ènìyàn ló ń bóbùn ún sòwò ni. àmó nígbà tí ó bá dé ojú eré, ó se àlàyé bí òsèfè yóò se gbé òrò rè kalè bí eni pé gbogbo ìsèlè òhún, ojú rè ló se. Ó sì tún se àpeere irú onà èdè tí òsèfè máa ń lò jù nínú eré won.
Nínú òrò ti Olúdáre Olájubù, ó se àlàyé kíkún lórí isé bótò nínú egbé olórin Ìlorin. Ó lo àwon àpeere láti gbé isé bótò gégé bí oníjó, alákòóso, agbódegbà, agbowó àti akéwì jáde. Ní ìkádìí, ó fún gbobgo onímò ìjìnlè pàápàá àwon afìmòwíwásisé ní ìsítí láti máa ye gbogbo akópa-nínú-orin wò fínnífínní, kí wón sì máa ko àkokún àwon orin tí wón bá gbà sílè lénu olórin, kí isé lámèyító ó lè kógo já.
Eré-enu ti àwon Èkìtì ni Omótáyò Olútóyè ko àpilèko tirè lé lórí. Ohun tí ó sì fà yo nínú rè ni àwon òrò tí àwon eléré máa ń fi wónyò sí eré won fún ìdí kan tàbí èkejì; tí àwon onímò sì ti máa ń kà sí àyàbá lásán. Olútóyè fi àpilèko rè àti àwon àpeere tí ó fà yo láti inú àsamò àti ùjaamèsè mú un dá ni lójú pé àwon òrò náà wúlò púpò nínú eré enu. Ó ní bí ó tilè jé pé irú wá ògìrì wá ni kókó tí irú àwon òrò bèè máa ń dá lé; síbè, àwon eléré máa ń lò wón fún àtifi ìmò kún ìmò àwon òwòran, àtikìlò ìwà, àtikóni lógbón, àti láti mú àwon ènìyàn agbègbè kan se àkíyèsí ohun pàtàkì kan yálà ní rere tàbí ní búburú, tí ó ń selè ní ìtòsí won.
Nínú ìwé tirè, Olúgbóyèga Àlàbá fi ìdí àbò ìwádìí rè múlè nípa isé tí àwon òrò àgbórérìn-ín ń se nínú ìgbésí ayé àyé àwon Yorùbá. Ibi tí ó gúnlè sí nip é isé òrò àgbórérìn-ín kò pin sí mímúni-rérìn-ín láti dá ni lára dá ni lára yá nìkan, wón tún wúlò láti gba ònà èro kó ni lógbón, wón sì tún ń lò wón láti to àjose tó bá fé wó láàrin àwùjo.
Ìtàn Fèyíkógbón Yorùbá ni babátúndé Ògúnpolú fi se àgbéyèwò aáyan Babalolá fún ìdàgbàsókè-ìjìnlè Yorùbá. Nínú àpilèko tirè, tí ó fi dá Babalolá lóla fún gbígbé ìtàn àbáláyé Yorùbá láruge dé òkè òkun, ó se àtúnpín ìtan Fèyíkógbón, ó sì se àlàyé tàpeere tàpeere lórí ipa tí ìtan Fèyíkógbón ń kó nínú ìgbéayéàwon Yorùbá. Ó tenu mó ìtan Fèyíkógbón Alálòó Àpamò, Ìtan Fèyíkógbón Arúmolójú Onísìírò àti Ìtàn Fèyíkógbón Arúmolójú Èwo-ni-káse nípa kíkó omo Yorùbá. Ní ogbón tí yóò fi we ilé ayé já. Ó fi kún òrò rè pé ìwádìí ń lo lówó lórí ipa tí Ìtan Fèyíkógbón ń kó nínú lítírésò òde-òni.
Àwon àpilèko yòókù nínú ìwé yìí tàn dé èka ìmò ìjìnlè Yorùbá tí Babalolá sisé dé. Olásopé Oyèláràn se àgbéyèwò ipá tí Babalolá sà nípa isé akómólédè Yorùbá. Nínú àpilèko tirè, ó se àkàwé àwon ìwé ìkónilédè tí babalolá ko àti ìwé ìlànà ìkóni tí N.E.R.C. gbé jáde. Ó wo gbogbo àròjinlè tí Babalolá fi kó omo lédé lónà tí èdè yóò fi wu ni í kó, àti ìlànà lìngúísíìkì tipá tipá tí kòríkúlóòmù N.E.R.C. fé kí akómolédè ó lò, ó wá dábàá pé kí á padà sí ese àárò tí Babalolá ti là sílè; kí èdè Yorùbá máa wá di àríbélùgbé fún àwon omo wa.
Ní orí keje, Bísí Ògúnsínà se aáyan takuntakun láti ye àwon ìwé olórò geere tí Babalolá ti ko wò. Ó fi sùúrù àti ìmò ìjìnlè se ìtúpalè imò ti ó wà nínú won, èkó ibè, àti ìhà tí Babalolá ko sí ìgbésí ayé àwon Yorùbá ní àkókó tí ó ko àwon ìwé náà. Kò sàìménu ba àwon ogbón ònkòwé tí Babalolá mú lò. Ògúnsínà fi hàn nínú àpilèko yìí, pé Babalolá fi àwon ìwé rè tóka sí èto àrògún àti ogbón ìbáraeni-gbé-pò àwon Yorùbá, ó sì fi ogbón yònbó èyí tí ó dára nínú àsà ìgbà náà, ó tún bu enu àté lu ìwà àìdáa láìfi òrò bopo boyò. Ògúnsínà wá fúnka mó on pé ohun tí Babalolá fi àwon ìwé rè se ni pé ó fé kí á mo irú ènìyàn tí ó fé kí omo Yorùbá ó jéníàwùjo, èrò rè (Babalolá) sì ni pé eni tí yóò bá jé asíwájú omo Yorùbá gbódò ní àwon èròjà ewà tí òun kó jáde lára àwon eni-ìtàn òun.
Ní tirè, ohun tí Tàlàbí Olágbèmí gbé yèwò ni lítírésò alohùn. Àlàyé jinná ni ó fi se isé yìí tí ó sì tú ìfun àti èdò èka lítírésò yìí jáde.
Àwon àpilèko méjì ni ó wà nínú ìwé yìí tí ó je mó ìtàn àti èsìn, kí ààrò méta tí obè ìmo Yorùbá dúró lé ó lè jókòó dáadáa. Ní orí kesàn-án, Oyin Ògunbà ko àpilèko tirè lórí Òrìsà Èkìnè ní ilè Ìjèbú. Kókó tí Ògunbà yo jáde àpilèko òhún nip é ìbásepò ti wà láàrin àwon Yorùbá àti àwon yòókù tí wón n gbé esè odò, ojó ti pé. Àlàyé rè lórí Èkìnè fi àjùmòsepò tó wà láàrin àsà àti èsìn Yorùbá hàn; ó sì fi ìyàtò tó wà láàrin egúngún àti Èkìnè hàn pèlú. Ohun tí àwon Ìjó fi ń se àríyá lásán, tí wón kàn fi ètùtù síse díè bò, ètùtù pereu ni, ìbo sì ni láàrin àwon Yorùbá Ìjèbú, tí ó gba òrìsà náà lówó won (Ìjó).
Òrìsà kejì tí àpilèko akínwùmí Ìsólá dé lé ni Sàngó. Ohun tí ó tún gbé òrò tuntun dìde lórí Sàngó nip é Ìsòlá ti wá rí i ibi tí a fojú sí nípa orírun Sàngó, ònà kò gba ibè rárá. Àbò ìwádìí rè lórí ‘Ta ni Sàngó?, Sàngó?, Sàngó mélòó ló tilè wà? Kí ni orúrun rè/won?’ àti béè béè lo ni a fi àpilèko yìí se. Ó sòrò títí, ó fi Ifá se elérìí.
Gbogbo àpilèko wònyí fi ibi ìjìnlè ti fè dé nípa èdè Yorùbá hàn. Wón kó òpòlopò èdè ìperí tí a ti kó jo jáde, wón sì mú un dá ònkàwé lójú pé iná ìwádìí, isé ònkòwé àti aáyan àtigbé èdè Yorùbá kalè ní fègbékègbé pèlú èdè yòówù ní àgbáyé, ń jó geregere. Àwon ìkádìí inú àwon àpilèko náà sì fi yé ni pé isé gbére ni isé ìwadìí, ó se é se kí ohun tí a fúnka mó gégé bí òótó lónìí di iró ní òla, ìwádìí mìíin ni yóò fi ìmò yìí yé ni. A lérò pé àwon àpilèko náà yóò bénà ìmò tuntun, kí wón sì ta ònkàwé jí gìrì láti se ìwádìí lórí èyí tí a kò tíì fè lójú tó. Ire o