Akoole Yoruba I

From Wikipedia

Akoole Yoruba

Akosile Yoruba

ÌTÀN ÀKOÓLÈ YORÙBÁ:

Ònà méjì ni a ó gbà fi wò èyí - Ònà kìíní ni ‘Ìtàn Yorùbá’. Ònà kejì sì ni ‘Àkoólè Yorùbá’. Òpòlopò Ìtàn ni ó ti wáyé lórí ibi tí Yorùbá sè wá. Iròyìn yìí yàtò sí ara won sùgbón gbogbo won gbàwí pé ń se ni Yorùbá sí láti àríwá ìlà-oòrùn wá sí ibi tí wón tèdó sí nísisìyí. Dr. Johnson so wí pé ilè ijibiti ni Yorùbá ti sè wá. Ó fi Nimrod oba Ijibiti tó rin ìrìn-àjò omo ogun lo sí ilè Arabia láti fi se ibùgbé sùgbón tí wón lée nítorí ìjà esin. Dr Luca fara mó èrò Johnson nípa títóka sí àwon èdè Yorùbá àti ti Ijibiti tí ó papò tàbí jora. AKIYESI:

Dr. Biobaku àti àwon egbé rè tako èrò. Dr. Lucas lórí èdè Yorùbá àti ti Ijibiti tí ó jora. Ó ní só seé se kí èdè papò nípa òwò. Ó ní à ti pé Dr. Lucas ti pón èrò rè ju bí ó ti ye lo. Dr Idowu fi èrò tirè hàn pé Olódùmarè ló rán odùduwà wá ní àsìkò ti gbogbo ayé kún fún omi. Odùduwà da iyanrìn tí olódùmarè fun láti òrun sí orí omi, eyelé wá tàn-án yíká, odùduwà àti ènìyàn mérìndínlógún wá sòkalè sí Ilé-Ifè tí ó jé orírun Yorùbá. Nígbà tí ó yá àwon Ìgbò bèrè sí fi ara hàn wón gégé bí iwin/òrò nípa dída imò òpe bora láti máa yo wón. lénu. Léyìn ìwádìí lódò òrìsà, Moremi (arewà obìnrin) yònda láti bá àwon Ìgbò lo sí ìlú won. Èyí mú kí ó ri àsírí àwon Ìgbò, ó wá padà wá láti tú àsírí náà fún àwon ènìyàn rè. Ó wá mú omo rè kan soso “Olúorogbo” láti fi rúbo sí àwon òrìsa fún èjé tí ó jé. Èrò àwon tí ó se àtúnpalè Bíbélì láti èdè Oyìnbó sí èdè Yorùbá ní nnkan bíi èéégbèwá odún (19th century) ni pé ‘àsà’àti èrò inú àwon Heberu kò yàtò sí ti àwon Yorùbá Nínú òpòlopò ìròhìn, a lè pinnu láìsiyèméjì pé àwon Yorùbá láti ibi kan wá sí Ilé-Ifè ni. Bíi èédégbèrin odún sí èédégbèfà odún ni a gbà wí pé ó jé àsìkò tí Yorùbá sí láti ibìkan wá sí Ilé-Ifè. Dr. Biobaku, léyìn òpòlopò ìwádìí rè gbà wí pé nípa àtìleyìn àwon omo Ijibiti, Heberu àti àwon kan ni odùduwà àti àwon ènìyàn rè fi dé ibi tí wón fi se àtìpó ní nnkan bíi èédégbèrin odún pèlú àkójopò òtòòtò. Adémólá Fasiku fara mó èrò Dr. Johnson sùgbón Professor J.A. Atanda tako èrò yìí, ó ní apá ìwò oòrùn ni odùduwà àti àwon ènìyàn rè ti wá. Bákan náà wón ní ìjà èsìn tó mú kí Odùduwa ní kí wón pa omo rè Bùráímò elésìn Mùsùlùmí ni ó múu sá kúrò ní ìlà oòrùn láti wá tèdó sí Ilé-Ifè níbi tí ó ti bá Àgbonmiregun (sètílù-onífá) pàdé. Lára nnkan tí wón kó dé Ilé-Ifè ni ère méjì àti àlùkùránì fún bíbo. Àwon kan so pé Òkànbí nìkan ni Odùduwà bí, àwon kan ni béè kó pé omo mérìndínlógún ni, àwon kan tún so pé méje ni. Ìtàn tí ó wá so pé Òkànbí ni ó bí omo púpò, pé méje sì ni, ni enu kò lé lórí jùlo - Olówu, Alákétu, Oba biini, Òràngún Ilé-Ìlá, Onisabe ile sabe, Olúpópó oba pópó, Oranyan ti Òyó Ilé. Ju gbogbo rè lo bí èyà kan se se àti bí wón se bá ìrìnkèrindò won dé ibi tí wón wà lónìí kò yé enikéni. Ìgbàgbó wa ni pé omo odùduwà ni gbogbo wa àti pé Ilé-Ifè ni ati sè wá. Ìsesí, Ìhùwàsí, àsà àti èsìn wa kò yàtò. Lónà kejì, àwon onímò Lìngúísíìkì se àkoólè Yorùbá Bowdich ati Clapperton lo kókó gbìyànjú kíko òrò Yorùbá sílè. Akitiyan àkókó láti gbé ìlànà àkotó Yorùbá kalè wáyé láti owó J.B. Raban (1830-1832). Akitiyan yìí ran Ajayi Crowther, Gollmer, M.D’Avezac lówó láti se àtúpalè èdè Yorùbá. Eléyìí mú kí ìjo. C.M.S. níbi tí Raban ti jé ajíhìnrere pàsè lílo èdè Yorùbá nínú ìsìn ní 1844. Ní 1824 – 1830 Hannah kilham se ìbèwò sí ìwò oòrùn Áfíríkà léèméta lórí kíko àkoto tó rorùn, tó sì já gaara. Ní 1875 asojú gbogbo ìjo pe ara won jo láti fi enu kò lórí ònà kan soso tí won yóò máa gbà ko Yorùbá sílè. Lára àwon kókó náà nìwònyí:

(i) Lábé, o, s, ìlà kékeré ni kí á fà, kì í se kíkánmo sí nídìí

(ii) ‘gb’ kìí se ‘bh’ tabi ‘b’

(iii) P (kì í se ‘kp’)

(iv) Àtòsílè àwon òrò tí wón ní édà èka-èdè, U tàbí O nínú ìró àrańmúpè. O dúró nínú àbàwón; U nínú àdánù.

(v) Òfin lílo àmì-ohùn

ÀKOSÍLÈ TI O N SO NÍPA ORIRUN YORÙBÁ

Aáyan àwon onísé ìwádìí láti topinpin àwon Yorùbá ló gbé wa lo sínú àkosílè tí ó kókó ménu bà èyà Yorùbá. Irú àkosílè béè ni a gbó pé ‘Sultan Bello’ tíí se eni tó te ìlú sokoto dó, ko sílé ní èdè Hausa. Àkosílè yìí ni Captain Clapperton nínú isé Sultan Bello tí í pe àkolé rè ní “History of the Sudan”. Sultan Bello so báyìí nípa àwon Yorùbá, pé àwon èyà tí ń gbé ní agbègbè (Yarba) jé àrómódómo omo kénáànì, tí í se èyà “Nimrodu” ó tè síwájú láti so fún wa pé ohun tí ó sín won dé ìwò oòrùn Afirika ni lílé ti Yaarooba tí í se omo Khanta lé won kúrò ní ilè Arabia sí ààrìn ìwò oòrùn láàrin ilè ifibiti si Abyssiana, àti agbègbè ibè wón tí wo ààringbùngbùn ilè Afirika wa tótí won fi i tèdó sí ibi tí won fi se ibùdó báyìí tí a mò sí ilè Yarubá èyí ní Yorùbá. Nínú ìrìn àjò won, won a fi èyà won sílè ni ibikíbi tí wón bat i dúró. Ìdí nìyen tí a fi gbà pé àwon èyà ‘Sudan tí ó ń gbé ni orí òkè orílè èdè jé èyà àwon omo Yorùbá. Ohun ti àkosílè yìí ń so ni pé ó se é se kí ó jé pé lára àwon èyà tí a mò sí Yorùbá lónìí ni ‘Sultan Bello’ ń tóka sí nínú àkosílè rè.