Ijinle Ede ati Litireso Yoruba 3

From Wikipedia

Ijinle Ede ati Litireso Yoruba 3

Olu Owolabi

Owolabi

Bayo Adereti

Adereti

Taiwo Olunlade

Olunlade

Afolabi Olabimtan

Olabimtan

Ede

Litireso


Olú Owólabí, Báyò Adérántí, Táíwò Olúnládé àti Afolábí Olábímtán (1986), Ìjìnlè Èdè àti Lítírésò Yorùbá: Ìwé kéta. Ìbàdán, Nigeria. Evans Brothers (Nigeria) Publishers Limited. ISNB: 978-167-519-8. Ojú-ìwé 101.

Èyí ni Èketa nínú òwó ìwé wa tí a dìídì se fún lílò lórí èdè Yorùbá ni ilé-èkó Sékóńdìrì àti ilé-ìwé èkósé àwon olùkóni. Gégé bí a ti se nínú àwon ìwé ìsaájú, a ta ogbón láti mú èkó inú ìwé yìí rorùn fún akékòó láti kó, a sì gbìyànjú láti to àwon èkó inú rè ní ònà tí yóò fi derùn fún àwon olúkó láti kó àwon akékòó. Ìsòrí méta pàtàkì ni a pín èkó nípa Yorùbá sí nínú ìwé yìí, èkó nípa gírámà èdè Yorùbá: èkó nípa àsà Yorùbá, àròko kíko; àti èkó nípa lítírésò Yorùbá. Olóyè Olu Owolabi, olùkó àgbà ní egbado College, Ilaro, ni ó gbájúmó èkó nípa àsà Yorùbá àti àròko kíko, Ògbéni Bayo Aderanti ti Oyo State College of Education, Ilésà ló sisé lórí èkó nípa gírámà èdè Yorùbá, Ojògbón Afolabi Olabimtan ti University of Lagos ni ó sì gbájúmó èkó nípa lítítésò Yorùbá (àtenudénu àti àpilèko) ìsòrí métèèta ni a pèsè èkó tí ó péye fún a sì fi èkó wònyí lú ara won kí ó má baà sú àwon akékòó. A se ètò àmúse-isé akékòó ní ònà tí olùkó yóò fi lè máa ni òye kíkún nipa ìwòn ìmò tí àwon akékòó bá ní nínú èkó ìjókòó kan. Nípa báyìí ìbéèrè lórí èkó kòòkan tún jé ìrànwó fún àkàyé. Dájúdájú, èkó akékòó gbódò tún wà lórì àgbóyé àti àsoyé èdè Yorùbá. Nítorí náà ó tó, ó sì ye kí àwon olùkó mò wí pé ogbón àtinúdá tiwon se pàtàkì púpò fún lílo èkó inú ìwé wònyí láti kó akékòó dé ojú àmì. Orísìírísìí ònà ni wón lè gbà láti se èyí. Díè nínú won ni:

1. Mímú àwon akékòó se ìwádìí nípa ewì àdúgbò tiwon alára, kí wón sì wá jé àbò ní kíláàsì

2. Lílo fíìmù àti fídíò tí ó fi ìgbé ayé àwon Yorùbá hàn;

3. Gbígba ohùn àwon akéwì àtenudénu àti ti apàló-padídùn sí orí èro agbòròso;

4. Kíkó àwon akékòó lo wo ayeye eré tàbí odún ìbílè orísìírísìí;