Akunyungba

From Wikipedia

Akunyungba

G.B.O. Olaleye

G.B.O. Oláléye (1979), ‘Akùnyùngbà’, DALL, OAU, Ifè, Nigeria.

Akùnyàngbà jé ìsòrí rárà kan. Òken nínú ewì àbáláyé ni rárà. Rárá pín si orísìí meta pàtàkì gégé bí mo se pín won sí ìsàlè yí:

(1) Rárà tí àwon obìnrin máa ń sun ní agbo ilé oko won. Oríkì orílè ni àwon obìnrin wònyí máa ń fi ń pe ìran oko won ní àsìkò àyeye tàbí ìsìnkú.

(2) Rárà ti àwon okùnrin máa ń sun láti fi kí Oba tàbí àwon ènìyàn ní ìgboro ìlú. Ìsòrí àwon asunrárà yìí kìí sáábà ní ìlù léhìn.

(3) Ìsòrí keta ni rárà tí àwon alusèkèrè máa ń sun pèlú ìlù. Níbi àríyá tí àwon ará ìlú bá ń se. Nígbà míràn àwon obìnrin a máa sun rárà pèlú ìlù.

Rárà Akùnyùngbà jé ti ìsòrí kìíní nínú ìsòrí tí a dárúko sí òkè yí. Sùgbón ìsòrí rárà Akùnyùngbà yàtò sí gbogbo ìsòrí rárà yókù fún àwon ìdí wònyí:

(1) Aláàfin àti àwon omo Oba nìkan ni won sun rárà Akùnyùngbà fún ní ìlú Òyó.

(2) Àwon ayaba nìkan ló máa ń sun rárà Akùnyùngbà.

(3) Ìsòrí meta ni àwon Akùnyùngbà wà ní ìlú Òyó:

(a) Akùnyùngbà Baba – Ìyajì.

(b) Akùnyùngbà Aláàfin.

(d) Akùnyùngbà Àrèmo.

Kò sí Àrèmo mó ní ìlú Òyó láti orí Aláàfin Gbádégesin ‘Ládígbòlù II (1956-1969). Ìdí yìí lo sì fà á tí ìsòrí Akùnyùngbà fi ku ìsòrí méjì ní ìlú Òyó ní àsìkò ti à ń se ìwádìí yìí.

Ònà tí won ń gbà sun rárà Akùnyùngbà yàtò sí awon ìsòrí rárà yókù. Bí won ba ń sun rárà yókù, eni kan tí ó jé ògá yóò saájú, àwon yókù yóò sì máa tèle e wí ohun tí ó ń máa gbe orin náà. Èyí ni a le pè ní lílé àti ègbè.

Sùgbón nínú rárà Akùnyùngbà, kò sí gbólóhùn tí ó wà lótò fún lílé, kò sí gbólóhùn tí ó wà lótò fún ègbè. Gbangbà ní won máa ń sun rárà Akùnyùngbà. Àwon asunrárà Akùnyùngbà yóò jókòó ní ìsòrí méjì. Won yóò sì máa sun rárà Akùnyùngbà ní lànfibò, èyí ni pé won máa ń wí kókó tí apa kìíni ń wí àti kókó tí apá kejì ń wí ní wonúwode. Igbà míràn apá kejì ni yóò parí kókó tí apá kìíní bèrè. Ìgbà púpò, kókó òtòòtò ni apá kìíní àti apá kejì yóò máa wí. Nípa sísun rárà yìí lónà báyìí. Ohùn àwon asunrárà yìí yóò waa sù dùdù; yóò máa kùn ní apá kìíní àti ni apá kejì, yóò sì máa dùn mó ènìyàn léti. Ìdí nì yi tí a se ń pe irú rárà yí ní “Akùnyùngbà”. Baba-Ìyajì (Olórí Omo-oba), Aláàfin, Àremò àti àwon omo-oba ni Akùnyùngbà máa ń seré fún.

ÌGBÀ TI A MÁA N SUN RÁRÀ AKÙNYÙNGBÀ

Àwon ojó méta ní o jé ojó pàtàkì tí Akùnyùngbà ní láti seré fún Aláàfin. Àwon ojó odún méta pàtàkì náà nìwònyí:

(1) Ojó odún Oòduà.

(2) Ojó odún Ifá.

(3) Ojó odún Beere.

(1) Ní ojó odún Oòduà, odò Oòduà ni won máa ń bo ní òkè Elétù ní Ìlú Òyó, Oòduà ní baba ńlá àwon Yorùbá tí ó sè won sílè ní Ile-Ifè kí àwon Yorùbá to lo káàkiri ibi tí won wà lónìí yìí. Ìdí èyí ni Aláàfin fi máa ń se odún Oòduà lódoodún ní ìlú Òyó. Àgbàlá kan sì wà ní ààfin Aláàfin tí à ń pè ní àgbàlá Oòduà. Nínú àgbàlá yí ni àwon ayaba tàbí ayomo tíí máa ń seré Akùnyùngbà lódoodún.

(2) Aláàfin a máa se odún Ifá ní odoodún. Ní ojó ti Aláàfin bá ń bo Ifá, ó jé dandan fún àwon Akùnyùngbà lati seré ní ojó yìí.

(3) Odún Beere je odún pàtàkì fún Aláàfin. Bí Aláàfin kò bá tì í se odún yìí, enikeni kò gbodò pa koóko beere láàrin ìlú láti fi kó ilé rè. Koóko beere se pàtàkì fún ara ìlú Òyó àti agbègbè rè ní ayé àtijó. Nítorí pé beere ní won fi máa ń kólé won kí ilé páànù tó dé. Ìdí èyí ni won fi máa ń so nínú ewì Òyó pé:


“Beere mólé,

Ó yele”

Ní ojó ti Aláàfin bá se odún beere, àwon Akùnyùngbà ní láti seré ní Ojú-Agbajú ní ààfin Aláàfin.

Àsìkò ti àwon Akùnyùngbà tún máa ń seré ni àsìkò ti enìkan bá kú nínú won; bí Aláàfin ba ń se àríyá tàbí ayeye kan; bí Baba-Ìyajì tàbí Aremo bá ń se odún kan tàbí àríyá kan; béè náà ní won tún lè seré fún omo-oba tí ń ba ń se àríyá kan. Sùgbón tí àwon Akùnyùngbà yóò bá seré fún omo-oba kan, omo-oba náà ní láti ránsé sí àwon Akùnyùngbà pé kí won wá seré fún òun.

ÀWON TI MÁA N SUN RÁRÀ AKÙNYÙNGBÀ

Kì í se gbogbo obìnrin lo lè sun rárà Akùnyùngbà. Orísìí obìnrin méjì tí ó lè sun rárà Akùnyùngbà ní:


(1) Ayaba (Ìyàwó Oba)

(2) Ayomo (Ìyà awon omo-oba àti ìyàwó àwon omo-oba).

KÍKÓ RÁRÀ AKÙNYÙNGBÀ

Ti obìnrin bá ti di ayaba tàbí ayomo ni yóò máa tèlé àwon tí ó bá níwájú. Yóò máa bá àwon yókù sun rárà yi títí tí òun náà yóò fi mò on. Eni tí ó ban í ìmò rárà yìí jù lo nínú àwon àgbà ayaba tàbí ayomo ni yóò je asíwájú. Nínú àwon ayaba àti àwon ayomo wònyí, a máa ń rí èyí to ti bá Oba méta tàbí mérin lògbà.

ÈTÒ ERE AKÙNYÙNGBÀ

Bí awon ayabà àti àwon ayomo bá fé seré Akùnyùngbà, won yóò kókó se ètùtù; nítorí pé won ka Akùnyùngbà sí ìsòrí rárà kan tí ó yàtò sí rárà tí àwon asunrárà máa ń sun lásán láti gbowó. Nínú rárà Akùnyùngbà, a máa ń dárúko àwon Aláàfin tí ó ti kú. Àwon ayaba àti àwon ayomo sí ní ìgbàgbó (títí di òní) pé òrìsà ni won, gégé bí baba baba ńlá won se jé òrìsà. Nítorí Ìdí yí bí won bá fé sun rárà Akùnyùngbà, won yóò pa àkùko adìe kan, gbogbo awon asunrárà Akùnyùngbà yóò sì fi eje rè ra àtànpààkò ese òtún àti tòsì.

Léhìn èyí àwon Akùnyùngbà yóò jókòó ni ìsòrí méjì:

(i) Àwon ti ń lé rárà Akùnyùngbà (ii) Àwon Atígbá àwon eléyìí yóò da ojú igbá délè, won yóò máa tí i, won yóò sì tún máa sun rárà lo bí won ti ń tí ‘gbá.

Tí ó bá jé ojó odún, bí odún Ifá, odún Oòduà àwon onílù Àgbèjà a máa seré pèlú àwon Akùnyùngbà. Àwon Àgbèjà yí yóò jókòó takété si àwon Akùnyùngbà. Àwon Àgbèjà yóò bu omi sínú ìyá-odó, won yóò da igbá de omi náà nínú odó. Won yóò máa fi òpá igi lù ú ní ònà ti yóò fi mú ohun dídùn wá.

Kí won to seré yìí Aláàfin yóò fun won ní ońje, owó, aso, eran àti adìe. Nígbà tí wón bá sì tún ń seré lówó, Aláàfin yóò tun fún won ni owó bí orí rè bá se wu tó. Àwon omo oba lókùnrin àti lóbìnrin àti àwon Ìjòyè tí won bá wà níbè, yóò sì máa fún won lówó. Bí orí oba bá wú, ó lè bo sí agbo kí ó jó. Ìdí èyí ni won fi máa ń ki Aláàfin kan tí ó féràn ijó ni:

“Jógbá, jágbè”.