Akewi ati Ede Re
From Wikipedia
Akewi ati ede re
ÀKÉWÌ ÀTI ÈDÈERÈ
Isé tí àwon onímò lítírésò tí gbé se lórí ewì kì í se kèrémí. Sùgbón ó se ni láàánú pé púpò ni kò sí ní àrówótó. Díè tó sì wà ní àrówótó; èdè gèésì ni wón fi ko ó fún ìdí kan tàbí òmííràn. Nítorí náà, a fúra pé a kò tíì túsu dé ìsàlè ìkòkò. Àti pé àwé-obì-kan-àjedóyòó ni isé inú ewì jé; Kò lè parí bòrò. Èbúté tí àwa fé kí àpilèko yìí gúnlè sí ni láti ya àwòrán irú eni tí a lè pè ni akéwì sí okàn àwon ònkàwé. A ó sì gbìyànjú láti júwe orísun èdè tíí máa lò àti báwo ni àbùdá rè se rí. Èyí yóò jé kí ó túbò hàn sí wa pé “isé ńlá nisé orín”. A ò sì tún mo ìyàtò tó wà láàrin “bababáwo” àti baba-aláriwo.
Ewì ni Adéagbo Akínjógbìn (1973) pè ní: “Orúko àjùmòjé tí a fún èyà àkosílè kan tí a máa ń fi ohùn dídùn so, tí a sì máa ń fi ohùn dídùn kà…” Béè ni. Sùgbón kí oríkì yìí baà lè ní ìtumò kíkún tí yóò bá àlàyé tiwa mu, ewì ni àwa ó pè ní àwon àsàyàn àsínpò-gbólóhùn aládùn tí a tí fi èdè tó pawó so di òwón, tí akéwì sì ti fi àrékun un-dá owó (nípa kíkosílè) tàbí ti ohùn re so di ogbón tó níye lórí àti ìjìnlè làákàyè lónà tí yóò fi ní ìtumò kíkún sí eni tó ń kà á tàbí eni tó ń gbó o. Ohun tí yóò fa irú ìtara yìí nip é onítòhún fura pé àwon àbápadé inú ewì náà ti inú ibú èdè, ìrírí, àsà àti àkíyèsí-ìrísí-agbègbè-eni tó je mó tàbí tí ó fara pé ti òun hù jáde. Ní òpòlopò ìgbà, kánàkò-èdè tàbí a-sun-àlàyé-kì ni àwon gbólóhùn ewì máa ń jé nítorí pé gbólóhùn kíkúrú inú won máa ń lóyún ìtumò tí yóò sì wá bímo àlàyé repete fún irúfé àwon ènìyàn tó bá mo rírì rè. Sùgbón lójú àwon ti kò bá yé (fún ìdí tí a ó ménubà níwájú) ajá ló ń gbó!!
Bí Olùfòn se fi gbogbo are jé séséefun ni ìgbési ayé ìrán yorùbá kún fún ewì. Bóyá ni a fi lè so èyí tí won ń lò púpò jù nínú ewì àti omío nítorí kò sí ìgbà tí a kì í lò ó - ojó ìpónjú tàbí ojó ayò. Ewì ni a fi n sunkún òkú kódà, ìbáà se òkú òfò. Bómodé bá kú, wón lè sunkún pé:
Moréniké lómú mi korò
O ló fomú ìyá òrun bonu
Àsàkè tòpá bò mi lójú
Ó ní ‘un tí n bá le se
Kí n máa se…
Mo té n ò dun bè.
Àgàgà bó bá jé òkú àgbà, won a ní:
Fágbénró bó ba délé
O kárá ilé
Bó o ba dónà…
Má wá pé lóko bi erú o
Má sì tètè dé bi omo òkú òle
Àsálé gbèré lomo olórò bò oko.
Nínú òrò wuuru ńkó? Àwon onítàn àròso pèlú ń yá ewì lò kí esè òrò wobn baà lè tólè. Àbí ta ni kì í pòwe? Ìsòròdorúko tí won fi ń gbé púpò nínú èdá ìtàn kalè pín lára àbùdá oríkì. Ewì sì ni. Àdán tilè ni àló lágbo lítírésò.
Sùgbón ta tilè ni Akéwì gan-an? Akéwì ni òjògbón olóhùn iyò tí ìrírí ayé rè peregedé. Etí rè kò di sí ìsèlè àdúgbò, ojú inú rè kò sì fó láti wo àtubòtán ohunkóhun Akéwì lójú òde pèlú èyí tí í fi í jérìí òrò. Ó mojú, ó mo ara. Lílo gbogbo èyà ara lónà yìí ni kì í jé kí akéwì lè sun àsùnpiyè lójókójó. Èyí ni Fálétí 91982) rí tó fi so pé:
Omi ti kò jàgbè lójú
Ó le dénú akéwì kó dòkun
Èfúùfù tó sì ń mòkun dòkun
Ó le dénú akéwì kó má jooru enu lo
Olóòrayè àti alákìíyèsí fínnífínní ènìyàn ni se pèlú. Ó béde, ó gbo èyò. E wá jé kí a máa mú àwon àbùdá wònyí lókòòkan.
Kí a tó lè so pé ènìyàn ń ké ewì, a gbódò rí kókó èkó kan pàtó kó nínú isé rè. Eni tí yóò sì dáso ró ni…Onà tí yóò fi gbé àrògún àti àròbájo rè jókòó kò gbodò tíì di gbáàtú-èyò àti méjì eépìnnì. Bátànì òtòlórìn fífi-sòrò báyìí ló fà á tí àwon olùgbón ewi fi máa ń mi orí léèkòòkan. Bí akéwì ti ń ronú ohun tí yóò kéwì lé lórí ni yóò m;aa finú ya fótò irú àwon ènìyàn tó fé ké o fún. Ó lè èka èdè won sín won je. Èwè, ó lójú irú nnkan tí a lè ké léwì ni sóòsì, ilé òòsà, ibi òkú tàbí ibi ìgbafàájì lásán. Ibùdó àti olùgbón ewì ló máa ń yan èrò àti ìlò èdè fúnra rè ìlú Oyó ni.
Gégé bi lítírésò àtenmudénu yòókù káàkiri òde àgbáyé kò sí òfin kan pàtó fún gígùn ewì Yorùbá nítorí pé síse ni won máa ń se é láré lójú agbo. Èyí mú kí ó di dandan fún akéwì láti jé eni ti kì í tijú. Won a máa se aájò sí gbogbo ìwònyí.
Òsèré àti olùdánilárayá ni àwon tí a bá pè ní akéwì, won kì í se alárògún nìkan. Àwon olùwòran dàbí alábàáse nítorí akéwì a máa gbése fún won lójú agbo. Akéwì lè má parí òrò rè délè tó jé pé àwon olùwòran ni yóò ronú bó se ye kí ó jé. Fún àpeere:
Erin ló pa kúkòyí ni
Enikan ò mò.
Kúkòyí ló pa erin ni
Enìkan ò mò
Sùgbón Kúkòyí ìbá pa erin ìbá bò
Irú isé mìíràn tí akéwì máa ń be àwon olùgbón ni títètè ronú ìtumò òwe tàbí àkànlò èdè. Bí ode kan bá so pé
Ogunlade o!
A-gbaya-lówó egbin
A-réjìká-rugi òké méfà roko
Onípèrègún igi àrígbà-yèwò.
Bí olùgbó kò bá mò pé ìbon ni igi òké méfà, ewì yìí kò le ní ìtumò. Kókó ohun tí a n so ni pé bí akéwì bá gbón féfé, olùgbó náà gbódò lánú bákan náà nítorí bí òye àwon méjééjì kò bá dógba bí omi okà tó hó sòfò ni isé akéwì yóò jo.
Isé mìíràn tí olùgbó tún ń se ni pé won a máa náwó, won a sì máa jánásì; won a sì máa gberin:
O káre
O ó jèrè
Ò o kú
Yinniyinni kéni se mìíí. E kú isé ní mórí isé yá.
Lóòótó, ohun àti èdè àbáláyè ni wón ń lò; àwon akéwì ń-sin ìrírí àtijo papó mó ti ìgbàlódé ni. Ní ìgbà mìíran èyí a máa fàáyé gba àmúlùmólà èdè. Àsà dídá sà tún wà lára onà yìí. Akéwì a máa lo èdè to tip e ti farasin tí ayé sì fé ga gbé. Fún àpeere ná-in sílífà, àdò àti béè béè lo.
Aláwáya, arinrin-un hùn-ún, asòtún-sòsi ma-ba-bikan-jé ni akewì. Bí a bá ń ló láti fi isé rè dá a léjó; ibáà se rere tàbí buburú. Mímó-ón-gé àti mímò-ón-won ló ń je béè. Enu akéwì gba òrò ni àwùjo ìran Yorùbá nítorí pé “Oba ki í pòkorin”.
Wàyi o, bawo ni èdè akáwì se rí? Ní sókí, èdè niyò ewì. Igbàgbó àti akéwi ni pé gbogbo ohun tó ba se e so lénu gbódò se é so yékéyéké tàbí so ní àsedun. Gbólóhùn a ti tún ro, tí a sì ti sun jinná korokorá. Tí jé Àwon èròjà ewi. A kò bu eran màwo bí a bá so ígbà náà pé omo tí èdè bí ni ewì jé. Sùgbón a rara pé bí a bá fi ojú bátànì sintaasi wo èhun fónrán gbólóhùn ese ewi, a lè rí ohun tó jo àsìlò níbè. Àsìlò kó, ara isé onà ni. Fún àpeere gbólóhùn ewì lè pa òrò-ìse je báyìí:
Kókó orí è (jé) egbèje
Ìlèkè ìdí è (jé) ègbèfa
Àkún owó è (jé) egbèìndínlógún
Gbólóhùn ewì a tún máa se àfikún òrò tí a fura pé kò ye kí ó wà:
Bíkú ò bá pa olùgbón
A bá so pékú járe re (ni)
Bíkú ò bá pArèsà
A bá so pékú jàre rè (ni)
Bí a ba lo asèrànwo òrò ìse bi (ki, bí, njé) láti bèrè gbólóhùn kan, a gbodo fi ìdajì gbólóhùn mìíràn gbè é lésè ni, ìbáà seèyí tó ni irú aseranwo òrò-ìse kan náà tàbí èyí tó ni sítírókísò mìíràn. Sùgbón nígbà mìíràn èwè, akéwì le to fónran ehun gbólóhùn ni àtòsódì. Fún àpeere, dípò
bí + APOR, a lè rí APOR + bi
Bi adie okoko ba je koko lagbala
Ibi omo ni fi su
Ó wá di;
Adie okoko bi o ba je”…..
Èyí fi pàtàkì adie okoko hàn jut i àkókó lo.
Àwon èdè eni tó-ti-sùn-kó-dìde ni akéwì máa ń fi lu koro pé òun gbé tuntun dé. Èyí lè jé òrò ìyanu:
E e è, e wáàá rajà omo Oba òoò
Tigi tòpè ní gbònwú àràbà
E yáa wá rajà omo Oba,
Èrò ká rebi iré gbe ń sè pòròpòrò bí omi omú.
Irú èdè dúndùn tíí ta ara àti okàn ji láti ìbèrè dé òpin gbódò lu inú ewì pa. Èyí di túláàsì kí agbo má baà túká mó on lórí. E wá jé kí a ménuba díè nínú àwon àbùdá èròjà ewì.
Nínú àfiwé, yálà elélòó tàbí tààrà ni àwon akéwì ti máa ń gbé isé fún opolo àwon olùgbó julo nítorí pé yóò nílò kí won fi èdá tàbí ìsèlè méjì wé ara won kí won sì mo ìbáré àti ìyàtò tó je yo. Ìgbà yìí ni ìtumò tó lè wáyé. Bí a bá so pé “Wèrè lòmùtí”a ti mò pé èdá kan ni wèrè, èdá mìíràn sì tún ni òmùtí. Kò ní la ni lóòógùn láti fi àwon méjéèjì wé ara won sùgbón nínú àfiwé bi i
Òpè lobìnrin
Eni tó bá ti nígbà ló ń gùn ún
Omi lènìyàn
Bó bá san síwájú.
Olùgbó gbódò mò pé orò tàbí dúkìá ni igbà dúró fún, kí ò sì mò pé kò sí ibi tí orí ò lè gbe esè èdá rè ni ìtumò ‘omi’ tó hàn nínú àpeere kejì. Àfiwé tí a kò sèsè túmò fún olùgbó tí kò sì ní ìtumò méjì tàbí èyí tó yàtò sí èrò akéwì nìkan ní kìí se àkóbá fún àsegbògo.
Ètò gbólóhùn jé ara ogbón ewì. Bí gbólóhùn inú ese ewì bá jé alákànpò tàbí àfibò, a lè to àpólà tó ye saájú séhìn. Àpeere àtúntò gbólóhùn báyìí ni
(i) Ó ń tan ara rè je
Afasé-gbèjò.
(ii) Kò gbàgbé enikan
Olórun Oba…
Onírúurú ètò báyìí ló wà: ètò olóòró, ètò oníbùú, ìfòrò-gbe-òrò, àhápin àti àwítúnwí. Àpeere ètò olóòró ni.
Ikú ń gbé ládéládé
Ikú ń ye lóyèlóyè
Ikú ń pa lákinlákin…
Àpeere ètò oníbùú ni:
E é ken lé
Ó yá ju eni a tì
Eni a tì
Ó yá ju eni a nà
Eni a nà
Ó yá ju eni a lu pa.
Àpeere òkè yìí náà lè dúró fún ifòrògbe-òrò.
Ìlò ìró wà lára èròjà ogbón ewì. Bí a bá fi ojú ìtumò wo àwon àsínpò ìró inú ewì nígbà mìíràn ìtumò won a máa fara sin. Fún àpeere
E mo dugbe àbi e ò mo dugbe?
E mo dùgbè àbi e ò mo dùgbè?
Béè mo dùgbè se be e mu dùgbèdugbe àdán…
Kó tó dàmódún towó-tomo ó ro lóòdè wa
Nítorí àbùdá èdè Yorúbà tó jé olóhùn, ònà tí a ń gba lo ìró nínú ewì pò. Díè nínú won ni:
(i) Àsínpò ìró:
Eran ìfà táya olófà kó nífà lófà Ló faya Olófà olófà kó nífà
(ii) Ifohùntakora:
Ó werin degbo réfúréfú
Kò bérin nígbó réfúréfú
Ó wérin dégbó réfùrèfù
Kò bérin nígbó rèfùrèfù
(iii) Ìró Àgbómòtumò:
Ikú pin nígbà yìí o
Ikú pin
Ikú pin làgbède sègún.
(iv) Ìfohùndárà:
Ong dowó rèng sang ong
Inang lóju’ng, ináng lénug
Ó dowó re Sàngó
Iná lójú iná lenu…
Àwon àpeere mìíràn ni ìwóhùn àti gbólóhùn dídógba. Àwon àpeere méta tó kehìn yìí lu inú Sàngó pipe pa.
Orísìí ogbón ewì mìíràn ni ewà èdè lílò. Èyí pò bí imí esú. A ti ménu ba díè léréfèé séhìn Adésígbìn (1983) si ti se atótónu púpò lórí èyi nínú ìwé Oòduà tó kojá. Díè nínú èyí tí ó ménubà ni àfiwé onírúurú, akanlo èdè, òwe, àwítúnwí abbl.
Ohun tó wá kù kí a ménu ba ni láti se àlàyé àpólà gbólóhùn kejì tó wà lára àkòrí òrò wa. Èyí ni “…èdè rè” (Akéwì àti èdè rè) ohun tí a n fi èyí tóka si ni wí pé “àdáni”ni ìsòwó èdè kan jé fún ìsòwó akéwì kan. Èyí ni pé bi a bá túmò ewì èdè sí èdè B kò ní jo ewì lójú D. Ohun tí a ń so ní pàtó ni pé iyò ewì tí a bá paláwòdà nípa títúmò sí èdè mìíràn ti di òbu pátápátá. Ta ló le mò ón pòn bí olómo!
Ìdí ni pé gbogbo ogbón tí akéwì kòòkan fi ń gbé ewì rè jókòó nínú èdè tirè kì í sáábà dógba mó ti èyà mìíràn nítorí àbùdá èdè kòòkan ti kì í papò àti ìrírí ìran omo ènìyàn ti kì í dògba. Ewì lórí ìjà esú, òwón iyò, ogun àgbékòyà omíyalé kò lè wuwo lókàn àwon Àgànyàn tó omo Yorùbá nítorí pé àwon ìsèlè yìí kò kàn wón gbòngbòn.
E jé kí a wo ibi tí èdè ti kan àtúntú ewì lábùkù nínú èdè Yorùbá pèlú Gèésì.
Ikú wá pin níugbà yìí o
Ikú pin
Ikú pin
Ikú pin làgbède sègún
Gèésì: Death has become powerless
Death has become powerless
That is what the blacksmith’s hammer says
When it struck on the anvil.
Àpeere yìí fi hàn pé ìró àgbómòtumò ti pòórá nínú àtúntú sí èdè elédè bíi gèésì. Nígbà mìíràn èwè, a kì í tilè rí òrò tó lè jé gbé-e-tán. Fún àpeere:
Ó sáré nínú igbó yelenkú yelenkú
Ó rìn ní bèbè ònà yelenkù yelenkù
Olórí asín-ìnrín dodongbá dòdòngbá…
Àtúntú a tún máa se àkóbá fún gígùn ese ewì. Kò sí bi a se lè túmò ewì kí ó má da ètò ohùn àti dídógba ese ewì rú. Fún àpeere:
i. Akinloyè – Heroism itself equals chieftaincy
ii. Pópóolá - Straight road of honour.
iii. Kóláwolé - That which brings honour into the house.
Àìdógba àsà kò ni sàìkóbá ewì tí a bá túmò sí èdè mìíràn pèlú. Bí akéwì ti n lo èhun gbólóhùn aládùn tó nnì, kò gbódò puró. Bí eni fi ìlèkùn mu ará eni lésè ni yóò jé bí akéwì bá lo hún irú ese ewì yìí mó isé rè fún omo Gèésì
i. Ìyàwó tí a fé nílé ijó
Ìran ni yóò wò lo
ii. Obìnrin ò jí kó má fìdí e hanlè
Obìnrin ò bo sokòtò
iii. Agbola ni tàgbònrín… àti béè béè lo
Nitorí wi pé iran tiwon kò ní ìgbàgbó nínú irú èrò báyìí bí a tilè túmo rè fún won lédè tí won gbó; kò ní níyi tó abéré lójú won.
E jé kí a wo ewì yìí wò.
Ajá ti n sòde rè
Ojó ti pé
Àgùntàn ti n sòde rè
Ònà jin
Kòìpé kòìjìnnà ti elédè
N sòde rè nínú eran.
Ewì yìí je mó ìtàn bí eran òsìn se wo ilè Yorùbá, èyí ti kò si lè rí béè ní apá ilè mìíràn, Irú èhun ewì báyìí ló je kí a lè so wí pé Èdá èdè àti asa je akéwì lógún púpò.
Ni ti ìlò ìró tí a ménu ba lókè. Àtúntú ewì sí èdè mìíràn yóò pa á lára. Ìdí ni pé ohùn kún ara àbùdá apààlà tí a fi ń mo èyà ewì kòòkan. Sóbò Aróbíodu so pé
Iye àèyàn tó wa nísé tísà
E fara wolúwá
E fèsè jìn.
Bí a bá ti tumò èyí si èdè mìíràn, a kò ní mò ón ni ewì Sóbò mó nítorí pé bátànì ohùn rè yóò ti pòórá.
Ayíká agbégbè tí ko papò náà wà lára ohun tó té àtúntú ewì. Bí a bá ni:
Tètè ìí té láwùjo èfó
Àlùbósà ló ní ki won ó sajú aláàánú mi jo.
Òòjó tí a bá gbé pósí wòlú
Òtòòtò èèyàn la fit a lóre.
Báwon ti a túmò ewì fún kò bá ni tètè ńkó? Bí wón tilè ní; sílébù “té” tàbí “sà” ara àlùbósà kò ní sùn le ara won bó se wà nínú èdè Yorùbá. Àbí kí a sèsè máa so nípa àwon India àti Larubawa ti won kì í lo pósí. Báwo wá ni ila 3 àti 4 òkè yen yóò se rí sí won.
Orísun ibi tí a fura pé akéwì tí ń rógbón dá ni nípa àrojinlè lóko-lódò, lósàn-án àti láàjìn. Àkíyèsí ìsèlè àti ìrísí àyíká. Àtinúdá àti àtúnro gbólóhùn. Won a máa ya èdè lò láti inú èdè mìíràn pèlú.
Ní ìparí, a ti rí i pé eni ti máa gbìyànjú láti rinú-róde ni akéwì se nítorí won máa n fi ara won sí ipò tí won bá rò pé ó ye kí olùgbó wa. Èyí ni yóò ràn wón lówó láti gbé ara won lé orí ìwòn. Èwè, a ti gbéná wo irúfé èdè tó fi ń sawo. Èyí tó sit i fi hàn wá pé bí a bá túmò ewì sí èdè mìíràn, bí ìgbà tí mààlúù múra láti lo ja gidigbò pèlú akegbé rè ni Lóńdóònù ni. Kombíìfù ni yóò bá darí wálé; esè ara rè kó ni yóò sì fi rìn bò. Bí a o ti se wo ewì mo níhìn-ín nìyí kí a máa baà di aláwòfín. Nítorí àwòfín, ló le mú òré bà jé, fírífírí lawo eni máa ń wo ni.
Abiodun Ogunwale
ÌWÉ TI MO YEWO
1. Abimbola, Wándé: An Exposition of Ifa Literary Corups, OUP, 1976 (p.99)
2. Taylor, Richard: Understanding the Element of Literature, Macmillan London, 1981.
3. Isola, Akinwumi: Ìwé Ìléwó lórí Sàngó Pípè
4. Babajamu, Malomo: Yorùbá Literature, Nigeria Publication Service, 1968.
5. Senanu, K.E. : A Selection of African Poetry Longman, 1980.
6. Àkànmú, Baba Belahu (YOL 001, oníjàálá.)
7. Olátúndé Olátúnjí: Adébayò Fálétí: A Study of his Poem, Hienemann, Educational Books Nig. Ltd., 1982.
8. Uchegbulam N. Abalugn Ed. Oral: Poetry in Nigeria, Nigeria Magazine, 1981.
9. Lijadu, Moses: Àwon Àròfò Sóbò Arobiodu Macmillan, 1976