Ofin
From Wikipedia
Raji Lateef Olatunji
ÒFIN
Yorùbá bò wón ní ìlú tí kò sí òfin èsè kò sí níbè. Akíyèsí ní pé òfin, ìlú àti àwon ènìyàn ko se yáà sótò. Òfin jé ìlànà kan pàtàkì láàárín awá omo ènìyàn fún dídarí ìgbésí ayé wa. Nínú ilé, èsìn, àdúgbò (igbéríko, ìbílè, ìpínlè, oríle-èdè àti ní àgbáyé) ní òfin tí ń darí awa omo ènìyàn. Tí o fí jé pé bí a bá rí eni tórú òfin agbègbè kan, á je ìyà gégé bí ìlànà tí won fí lélè ní irú agbègbè bé è. Bí a bá ní àwònfín lórí àwon nnkan tí Elédàá dá sí orí ilè-ayé a o ri wí pé, èyí tí ó sún mo awa omo èdá ènìyàn jù ní eranko, sùgbón won kò ní làákàyè gégé bí awa omo ènìyàn. Lílo òfin láàárín àwon èdá mìíràn pàápàá eranko, kò wúlò, nítorí pé won kò ní làákàyè fún ríronú, àti pé won kò ní ìlànà àti etò fún síse àwon nnkan tí won bá fé se. Làákàyè, èyí tí ó mu awa ènìyàn yàtò sí àwon èdá mìíràn ní ó mú won ní òfin tí won ń télè láàárín ara won. Òfin, láàárín awa omo ènìyàn ko fí àyè sílè fún enikéni tí ó bá lù òfin láti ma fún irú eni bé è ní ìjìyà tí ó tó tàbí tí ó ye. Bí a bá ronù jinlè lórí àwon ìgbé ayé tí ó ti kojá lo, a ó rì wí pé kò sí òkan nínú àwon ìgbé ayé yìí tí á le yàà òfin àti àwon ènìyàn inú rè sótò. Àpeere irú ìgbà tí mò ń tóká sí yìí ní ìgbá tí àwon oba ń darí ayé. Ní àsìkò yìí, oba àti àwon èmèwà rè ní àwon ìlànà tí won ń tèlé láti fí dárí àwon ènìyàn won. Bákan náà sin í irú àwon ènìyàn àsìkò bé è ní àwon agbára kan tí won le lò lórí àwon oba won. Bí a bá rí oba tí ìsesí rè yàtò sí ìlànà tí won fi lélè ti o wa ń fi agbára àti ipò rè ni àwon ará ìlú náà lára, àwon ènìyàn ìgbà náà won a lò agbára won gégé bí òfin láti yo irú oba bé è. Àpeere ti o sún mo wa jù lóòní tí a lè tóka sí nílè Yorùbá ni ìlú ÒYÓ. Bí wón ti ní oba, wón ní àwon ìjòyè bi Balógun, Basòrun, Àgbà-Akin, òyó mesi, tí gbogbo won sì ní isé tí wón ń se gégé bí òfin. Bí òpò èsìn ti wà, gégé bi èsìn àbáláyé, èsìn kirìsténì àti èsìn mùsùlùm. Won ní àwon òfín tí ń darí awa ènìyàn nínú àwon èsìn wonyìí. Àwon oludari èsìn fí ye wa wí pé àwon òjísé ní wón mú àwon òfin yìí wa fún wa láti òdò Elédàá ayé òhun òrun, fún dídarí wa lórí ilé-ayé. Nínú àwon òjísé tí agbó náà ni: Mósè, èyí tí ó mú òfin mewa inú Bíbélì wa. Jesu, èyí tí ó mú àwon òfin ìgbé ayé ènìyàn wa nínú Bíbélì. Bákan náà, Muhánmódù èyí tí ó mú òfin tí wón ń pè ní Alukuram wa fún dídarí àwon omo ènìyàn àti àwon mìíràn béèbéè lo yàtò sí àwon èsìn wonyìí. Gbogbo àwon èsìn mìíràn tò kú ní wón ní ìlànà tí o jemó òfin tí àwon ènìyàn inú èsìn náà sí gbodò tèlé, tí á bà wá rí eni tí ko tèlé irú òfin bé è, ìjìyà wa gégé bí ìlànà won. Ayé tí a wà lóòní tí fejú ju tí atèyìnwá lo. Ètò awa ènìyàn sí tí pò bákan náà. Ní òde òní a ó rí ilétò, abúlé, ìlú, ìbílè, ìpínlè, oríle-èdè. Gbogbo àwon wònyí ní wón ní ìlànà tí won ń tèlé (ofin),. Orílè-èdè ní òfin tí ó jé olúborí fún ìpínlè tí ń be lábé rè, tí àwon omo oríle-èdè bé è sì gbodò tèlé. Bákan náà, oríle-èdè náà wà lára àwon àjo míràn lágbàáyé tí òun náà ní àwon òfin tí o gbòdó ma bòwò fún gégé bi omo egbé. Bí òfin ti se wà ní a ní àwon èka kan tí won n mójú tó àwon òfin wònyí. Ní oríle-èdè, àwon yìí à lé pè ní agbófiró, adájó, agbejérò àti àwon míràn béè béè lo. Ilé-ejó (kóòtù) ní won ma ń lò láti se ìgbéjó àti dídájó eni tí a fi èsùn kan, tí a ò tí rí àrí dájú wí pé irú ènìyàn béè jèbi òrò. Òfin wúlò ní gbogbo isé tí omo ènìyàn ń se tàbí gbogbo èka tí omo ènìyàn lè fé yà sí. Àpeere ní òrò èsìn, òrò-osèlú, orò ajé, ìléra èkó, eré ìdárayá àti béè béè lo. Bí kò bá sí òfin ní irú àwon nnkan báyìí, ìgbé ayé omo ènìyàn kìí bá tí rorùn, wàálà kò bá tún pò láàárín awa omo ènìyàn. Bá wo ni ayé kò bá ti rí bí kò bá sí òfin? Olówó kò bá lo owó rè láti fí mú eni tí kò ní sìn bí erú. Béè ni Alágbára kò bá lo agbára rè lórí eni tí kò lólá, tí enìkan kò ní lè bi léèrè. Àgbàlagbà kò bá lo ipò rè láti ré omodé je. Eni tí kò lólá kò bá wá rí bi eranko ní iwájú olóla. Ki a dúpé lówó Elédàá bí ó se se awa ènìyàn ni olúborí àwon èyà mìíràn tí ó dá, nípa fífún wa ní ogbón, ìmò, oyé àti làákàyè tí ó pé láti lè mò ohun tí ó tó yàtò sí èyí tí kò tó àti láti lè darí ara wa pèlú ìlànà ètò òfin. tí ó dara jù ló.