Eegun Alare
From Wikipedia
Eegun Alare
==Oju-iwe Kiini]] Eegun Alare
[edit] Oju-iwe Kiini
Eégún Aláré
1
Òjè Lárìnnàká àti Dásofúnjó
Òré tímótímó ni Òjè Lárìnnàká àti Dásofúnjó ní Òkèehò. Òjè Lárìnnàká lo pidán ní ìlú kan tí idán pípa ti tà. Ìdíwó ilé kò jé kí Dásofúnjó lo ní tirè. Aya Òjè Lárìnnàká tí ó ń jé Iyadunni ti lóyún ní àkókò yìí. Òjè Lárìnnàká dágbére fún àwon ebí rè àti fún Dásofúnjó. Dásofúnjó fún un ní ìwon nnkan tí ó ní tí ó lè fi se agbára kún èyí tí ó ní tí ó lè fi se agbára kún èyí tí òun náà ní. Ó dágbére fún ìyàwó rè ó sì sèlérí láti wá mú un kí ó tó bímo. Àwon omo èyìn rè gbé òkètè tí ohun èlò ìpidán wà nínú rè rù wón sì mú ònà ìrìnàjò won pòn. Ìyádùnní sìn wón sónà ó sì fi èsà ki oko rè. Èsà ni ewì tàbí iwì eégún.
Nínú èsà tí Iyadunni fi ki oko rè ni a ti rí i pé Ìrèmògún, ará Ìlágbéde, eni tí ó máa ń lu irin tí ó ń tún un ún se ni Òjè Lárìnnàká. Ìyádùnní be oko rè nínú èsà yìí pé kí ó má gbàgbé òun nítorí pé lílo tí ó ń lo, kò dá ìgbà kankan tí òun yóò padà.
Òjè Lárìnnàká náà fi èsà dá aya rè lóhùn pé ki òun náà má se gbàgbé òun.
Dásofúnjó se ìtójú ìyàwó òré rè dáadáa. Títí tí ìyàwó fi bímo Òjè Lárìnnàká kò dé. Dásofúnjó àti àwon ebí ni ó so omo náà ní Ojélàdé fún esèntáyé omo yìí tí wón lo yè wò lódò babalawó odù òsá méjì ni ó go lójú ópón. Ese Ifá yìí so pé isé baba re ni omo yìí náà yóò se. Ifá ní ‘…Awo ààsàì goróyè’. Wón ní kí won rúbo. Awon ohun ebo sì ni eyelé mérin, àgbébò adìye mérin, obì gidi mérin àti òpá aso mérin. Wón rú ebo yìí.
Léyìn odún méwàá tí ó ti bímo, Ìyádùnnì pinnu láti wá oko rè lo nítorí pé lójú rè, oko eni kú sàn ju oko eni nù lo àti pé wo ìsò dè mí kò lè dà bí onísò, ojú méwàá kò sì lè jo ojú eni. Ìyádùnní ní, lóòótó, Dásofúnjó tójú àwon síbè, àwon nílò láti wá Òjè Lárìnnàká lo.
Léyìn odún kan ti Ìyádùnní àti omo rè ti kúrò ní ilé, wón pinnu láti dúró ní ìlú kan láti sisé díè nítorí pé owó ti ń tán lówó won. Wón ń gba àárù láti fi lè rí owó díè. Léyìn ìgbà tí wón ti se eléyìí fún ìgbà díè ni wón bá pinnu láti padà sílé nítorí pé bí iwájú kò bá seé lo, èyìn á á seé padà sí.
Nígbà tí wón dé ilé, wón fi Òjélàdé sí òdò Dásofúnjó láti máa kó idán pípa. Dásofúnjó kó o ní isé yìí fún odún méwàá, ó sì yege. Léyìn ìgbà tí Òjélàdé ti kó isé tí ó yege tán ni ó pinnu láti wá ire tirè lo sí ìlú mìíràn nítorí pé “Erin kìí fon kí omo rè fon”
Kí Òjélàdé tó lo, Dásofúnjó fún un ní omo rè, Ànséètù láti fi saya. Ní ojó kejì léyìn ìgbéyàwó ni Òjélàdé, ìyàwó rè àti àwon omo isé rè lo sí àjò. Nígbà tí wón dé ìlú kan, wón pinnu láti fi ibè se ibùdó kí wón sì máa ti ibè lo máa saré ní ìlú mìíràn. Tí Òjélàdé bá ń lo seré kì í mú ìyàwó rè dání nítorí pé kì í lo àlosùn. Nígbà tí ó se, Baálè ken pè é pé kí ó wá seré fún òun. Nígbà tí Òjélàdé ń lo jé Baálè yìí, ó mú ìyàwó rè dání.
Ìrìn ojó méta ni ìlú yìí. Nígbà tí wón dé ibè, wón fi wón wò sí ilé Balógun ìlú yìí. Kí wón tó seré Òjélàdé àti ìyàwó rè jo lo kí àgbà eégún aláré kan ní ìlú yìí. Wón fún un ní èbùn. Òjélàdé so fún bàbá yìí pé òun wá saré ní ìlú náà ni. Bàbá yìí sì kí won dáadáa sùgbón gbàrà tí ó ti rí ìyàwó Òjélàdé ni ó tin í ifé rè gidi gan-an nítorí pé obìnrin tóí ó léwà púpò ni.
Bàbá yìí be ìyàwó Òjélàdé pé kí ó fé òun sùgbón ìyàwó Òjélàdé kò jálè. Nígbà tí Ànséètù so fún oko rè nípa òrò yìí, oko rè lo ba bàbá yìí bàbá yìí sì so pé òun ti gbó. Ó ní òun kò mò pé ìyàwó rè ni. Kí ó tó di pé Òjélàdé be bàbá yìí kí ó tó gbà gan-an, bàbá yìí ti lérí pé òun lè pa Òjélàdé tí ìyàwó rè bá kò láti fé òun. Sùgbón gégé bí a se so sáájú, Òjélàdé be bàbá yìi, ó sì so pé òun gbà Òjélàdé.
Ó se wón dá ojó eré. Ní ojó eré, wó kerèé ó ta òkìtì, ó di Òyìnbó, ó di olópàá ó sì di ekùn. Nígbà tí ó wó kerèé, ìyen nip é nígbà tí á di erè (ìyen òjòlá) ni Òjélàdé kò bá lè yí padà di ènìyàn mó. Oníbàtá ń so pé kí won la òjòlá kí won gbé omo ènìyàn jáde. Bí wón ti ń la òjòlá ni Òjélàdé ń so pé ara òun ni wón ń gé. Òjélàdé bèrè síí pèsà. Ó pè é dé ibi tí ó ti so pé “Lárínnàká, oko Iyadunni” ni bàbá òun.
Bí ó ti pèsà dé ibí yìí ni bàbá kan bá jáde tí ó so pé omo òun ni Òjélàdé àti pé òun ti fi owó ara òun se ara òun. Ó ní òun ni òun se Òjélàdé nítorí pé òun fé gba ìyàwó rè. Ó tún se àlàyé síwájú sí i pé omo òun ni Òjélàdé àti pé ìyá rè ní oyún rè sínú ni òun kúrò ní ilé. Ó ní àdámò ni ó dà fún òun. Báyìí ni àwon èrò ìwòran se so ó di “Bàbá Àbámò”. Wón ní kí bàbá yìí lo mú èrò wá.
Ó lo mú ìdó kan tí ìkóóde wà lénu rè wá ó sì gbé sìgìdì kan tí ó ń rin sin-in fún epo dání. Ó bèèrè fún èjè ewúré, Baálè wá a fún un. Ó ní kí won, ta kerèé yípo òjòlá náà, wón sì se béè. Ó dúró sí èyìn kerèé náà, ó fi èjè ewúré yí àdó oníkóóde náà. Ó mú àdó sí owó òtún, ó gbé sìgìdì sí owó òsì, ó sì bèrè síí pe ofò.
Léyìn ofò yìí, Òjélàdé jáde kúrò nínú kerèé. Òjé Lárìnnàká fi èsà dúpé lówó Baálè wón sì korin pé, “E jé ká relé, ilé là ń lo; Àjò kan kò gbeni gbeni, kó dàbí ilé”. Wón padà sí ìlú won.
II
Òjélàdé Omo Ojè Lárìnnàká
Léyìn ìgbà tí wón ti padà dé ilú tan ni Òjélàdé bá tún múra àtilo sí àjò mìíràn. Òjé Lárìnnàká ti dàgbà nígbà náà. Ó fi òpòlopò agbára rè han omo rè. Kò pé léyìn èyí tí ó fi kú. Omo rè se òkú rè fún osù méta
Léyìn ìsìnkú yìí ni Òjélàdé wá múra ìrìnàjò rè. Nígbà tí ó dé ìlú kan tí ó ti fé saré, ó lo láti gbàyè lówó Baálè, oníyen sì fún un. Ní ojó eré, gbogbo ènìyàn pé jo láti wòran. Ní ojó yìí, Òjélàdé kò júbà kí ó tó bèrè eré gégé bí ó se máa ń se télè.
Dípò tí Òjélàdé ìbá fi kókó júbà kí ó tó bèrè eré, ofò ni ó ń pè pé, “A kìí ráféfé mú…” A kò mò bóyá páàgùn ni ó ń dà á láàmu nítorí pé “ó gbékè lé agbára tí bàbá rè fún un”. Nínú èsà rè, ó ki Baálè ní “Ìkòyí omo erù Ofà”
Nígbà tí Òjélàdé ki Baálè dé ibi tí ó ti so pé, “Èsó Ìkòyí, dá mi lóhùn ìwo ni ng ké sí” ni Baálè ni Baálè àti àwon ìyòyè bá fún Òjélàdé ní òpòlopò owó Baálè sì tún fún un ní Omobìnrin kan kí ó fi se aya. Òjélàdé fi èsà dúpé. Léyìn èyí ni ó bèrè síí pidán.
Ibi tí Òjélàdé ti ń pidán ni àwon àgbà òjè tip é kí ló dé tí kò júbà kí ó tó bèrè eré. Orin àrífín ni Òjélàdé fi dá wo lóhùn pé, ‘Ìkòkò tó fojú deyìn, a fó…”. Àwon àgbà òjè yìí wá dan án. Ó di ònì, kò lè yí padà di ènìyàn mó.
Nígbà tí Òjélàdé ti rí i pé òun kò lè yí padà di ènìyàn mó ni ó bá fi èsà so fún omo èyìn rè kan tí orúko rè ń jé Òjékúnlé pé kí ó lo bá òun mú èrò kan wá. Ó ní ‘O ó bá mi délé babami. Àdó kan ń be lájà a-mi-ló-ló-ló’. Àdó yìí ni Òjélàdé fi èsà so fún Òjékúnlé pé kí ó bá òun mú wá. Bí Òjékúnlé ti gbó ni ó ti mú ònà pòn láti lo mú àdó náà wa. Kí ó tó padà dé, òjó ti sú ó sì ti rò lé ònì lórí. Bí òjò yìí se rò lé e lórí ni ó bá wó wo inú omi lo. Etí omi yìí ni ó wà tí obìnrin kan wá sí etí odò yìí láti da eèrí nù. Bí ònì ti rí obìnrin yìí ni ó pe èsà sí i. Èrù ba obìnrin yìí bí ó se rí ònì tí ó ń pé èsà ó sì fi ìbèrùbojo da eèrí orí rè nù. Bí eèrí ti ó dànù yìí se kan ònì yìí lórí ni ó bá yí padà tí ó di ènìyàn, ìyen ni pé ó yí padà ó di Òjélàdé.
Òjélàdé wá tèlé obìnrin yìí lo sí ilé. Nígbà tí ó dé dé obìnrin yìí, ó se àlàye gbogbo ohun tí ó selè fún òun àti oko rè. Òko yìí ni ó sì fún un ní aso tí ó wò lo sí ilé. Ó tilè dé ilé sáájú àwon omo èyìn rè.
III
Òjélàdé di Baálè Arèkú-Eégún Èdìdì tí a mú di ìrókò olúwéré, ara ló fi san Báyìí ni ó rí fún Òjélàdé. Lékèé gbogbo ohun tí ó selè sí i, ń se ni òkìkí rè ń kàn sí i. Ó se, òkìkí rè kàn dé òdò Aláàfin. Aláàfin wá pè é pé kí ó wá fi iga gbága pèlú Dúdúyemí kí won fi lè yan eni tí yóò je ‘Baálè. Arèkú Eégún’. Ìyàwó rè kékeré tí Baálè fi ta á lóre bè é pé kí ó má lo sí ibi ìdíje yìí, kò gbà. Ó ní ijó ‘Ijó eégún kì í hun bàtá, àborúboyè kì í hun omo Awó. Ó ní isé bàbá òhun kò lè hun òun. Ìyàwó yìí bè é títí, ó fi orí so ó láyà, ó sì dákú. Nígbà tí ìyàwó yìí jí, Òjélàdé fi lókàn balè pé, ‘Odíderé kì í kú sóko ìwáje, béè ni omo inú odi kì í kú séyìn odì’. Nígbà tí òrò ti rí báyìí ni Ànséétu, ìyen ìyàwó tí ó dákú tí ó sì jí yìí bá so pé òun yóò bá won lo, Òjélàdé sì gbà fún un láti bá àwon lo sí ibi ìdíje náà. Èsà pípè, àti ijó nìkan ni wón fé fi se ìdíje.
Òjélàdé kò jé kí iná èsìsì jó òun léèméjì, ìbà, ni ó kókó jú lójú agbo. Léyìn ti ó júbà tán, Dúdúyemí náà júbà. Léyìn èyí ni Òjélàdé wá fi èsà so àwon itú tí ó ti pa. Dúdúyemí náà fi èsà so itú tí òun náà ti pa. Ní ìparí èsà Dúdúyemí ni ó tip e Òjélàdé níjà pé kí ó fi èsà kí àwon Ológbùró. Òjélàdé kì wón. Ó so gbogbo ohun tí wón ń se àti èyí tí won kì í se. Ní ìparí, ó ní kí Dúdúyemí èsà sàlàyé eni tí ó kókó gbóyín Ògburò lo sódò tó pòsé. Dúdúyemí so pé ìyàwó Ológburò nì. Ó ní òun ni oyún inú rè jáde tí ó sì gbé rù ú ní odò. Nígbà tí obìnrin yìí dé ilé, ó so fún oko rè. Wón dífá, Ifá so pé okùnrin ni omo náà yóò jé àti pé ogun ni yóò máa jà. wón bí mo tán omo kò yéé sunkún nì wón bá gbé e jù sí, inú igbó. Nígbà tí won yóò fi padà dé ibè ní ojó kerìndínlógún, won kò bá omo mó. Omo ti bójú ogun lo. Bí Dúdúyemí ti dáhùn báyìí tán ni òun náà bèèrè ìbéèrè lówó Òjélàdé lórí Ológbùró ken náà. Òjélàdé sì dáhùn pé, ‘Oníkòyi lomo tí wón gbé jù sí gbàgede rè. Òun lÈsó Ìkòyí, omo erù Ofà’. Ogun tí omo bá lo, nígbà tí ó di odún kerìnlélógún tó tì bógun lo ni ó ránsé wálé pé kí won ó bá òun kí bàbá òun, ‘Omo a jáwé gbogbo pè é lóògùn’. Oríkì rè yí fi hàn pé onísèègùn ni. Dúdúyemí ní òótó ni Òjélàdé ń so. Òjélàdé náà wá ni kí Dúdúyemí bá òun dé, ‘Ilé Èdè Òdí Mode Ìresà’. Dúdúyemí náà fi èsà dá a lóhùn ó sì fí yé nip é isé epp síse ni isé won. Bí Dúdúyemí ti parí ni ó so fun Òjélàdé náà pé kí ó so ohun tí ó jé èèwò nílé ará Ìresà.
Òjélàdé fi èsà se àlàyé ohun méta tí ó jé èèwò won. Won kì í fi kèké retí. Won kì í fi kèké ròfó. Won kì í fi agbada dínran je. Dúdúyemí náà tún gbà á lénu Òjélàdé léyìn ìgbà tí ó ti so pé òótó ni Òjálàdé ń so. Ó ní, Ìrù esin lòòsà nílé ara Ìresà’béè ni, ‘Ikin níí gbe ni’. Bí Dúdúyemí ti so eléyìí tán ní Òjélàdé wá bi í pé ta ló kókó rèkú eégún, ìyen ni pé tan i eégún àkókó ní ilé ayé. Dúdúyemí dáhùn pé Ológbojò ni, ìyen. ‘Èsà Ògbín, ará Ògbojò’. Duduyemí náà wá bi í pé ta ni ó ni eégún gan-an. Òjélàdé dáhùn pé Àrè Òjé Olójowòn ni ó ni ín kí Èsà Ògbín Ológbojò tó bá agbé e. Léyìn èyí ni Dúdúyemí wá ki èsà tí ó sì sàlàyé bí wón se ni kí àwon eégún lo ponmi wá tí àwon àgbààgbà méje òde Ògbín-ilé yóò mu lé kóókò tí wón sun je lóko lásìkò tí ìyàn mú. Eégún méfà ni ó kò láti lo pé tí àwon bá lo tán, won yóò gba àgó lówó àwon. Èkéje tí ó lo, òhún tí ó rí òkú eégún tí ó fó agbè mólè ni eégún tó jí.
Léyìn tí Òjélàdé ti so pé Dúdúyemí yege tán ni Dúdúyemí wá bèèrè lówó re pé ibo ni Yorùbá ti sè. Òjélàdé sì dáhùn pé Ifè ni. Léyìn ìgbà tí Òjélàdé ti dáké tán tí àwon ènìyàn sì ti pàtéwó fún un tán ni obá bá pa á láse pé kí wón pa ìtàn síso tì kí won wá ohun mìíràn se. Bí oba ti so eléyìí tán ni Dúdúyemí bá ki enu bo èsà ó sì so bí Òjélàdé se di ere àti bí ó se di òòni tí ó jé pé obìnrin kan tí ó lo da ògì nù ni ó jé kí ó yí padà di ènìyàn láti ipò òònì tí ó wà. Léyìn èyí ni Òjélàdé náà wá fi èsà so pé se kí òun náà wí o, sé kò níí sí nnkan. Oba, Dúdúyemí àti àwon ènìyàn ní kí ó máa wí. Bí wón ti gbà á láyè yìí ni Òjélàdé wá fi èsà wí pé Àmòó tí ó jé bàbá “Dúdúyemí di mààlúù ó sì wogbó lo. Ó ní nítorí ìdí èyí ni Dúdúyemí se ń hùwà bí eranko. Òrò yìí dun Dúdúyèmí. Àwon ènìyàn ń fi se yèyé wón sì ń fi owó fo Òjélàdé lórí. Dúdúyemí wá yo ìwo kan ní àpò, ó pe ofò kélékélé sí i ó sì so fún Òjélàdé pé kí ó tún ìtàn rè pa.
Bí Òjélàdé ti fé máa pèsà báyìí, gbígbó ni ó ń gbó bí ajá. Ìyàwó rè, Ànséétù rí ohun tí ó ń se é, ó wá lo sí ibi òkètè oko rè ó sì mú oògùn kan jáde, ó bèrè síí pofò. Kò pé léyìn tí ó ti ń pofò yìí tí oko rè bèrè síí pèsà ó sì fi ewà ìyàwó rè wé ti Sábárúmó, ìyen fúlàní. Léyìn ìgbà tí Òjélàdé ti sojí yii ni ó wá so fún Dúdúyemí pé kí ó bá òun ki ‘Ìyèrú Òkún Olófàmojo nílé Olálomí’, ìyen oríkì ìyá oba. Bí Dúdúyemí se nì kí òun máa sòrò báyìí ikó ni ó ń hú tí èjè sì ń dà lénu rè. Gbogbo oògùn tí ìyàwó àti àwon omo èyìn rè se fún un kò sisé.
Lékèe gbogbo ohun tí ó ń selè yìí orin ni Òjélàdé àti ìyàwó rè ń ko tí wón sì ń jó tí wón ń korin tí gbogbo ènìyàn sì ń wòran won. Nígbà tí ó se, obá so fún Òjélàdé pé kí ó tú Dúdúyemí sílè. Òjélàdé se bí oba ti wí. Oba wá so pé Òjélàdé ni ó yege ó sì fi je Baálè arèkú eégún. Dúdúyemí lo bá Òjélàdé ní ibi tí ó ti ń jó. Oba ní kí Dúdúyemí júbà fún Òjélàdé gégé bíi ‘Baálè arèkú eégún. Dúdúyemí sì se béè’. Léyìn èyí ni Òjélàdé wá fi èsà ki Ìyèrú Òkín Olófàmojo. Bí ó ti se èyí tán ni oba bá fi omo rè kan ta á lóre kí ó fi saya.
Òjélàdé fi èsà dúpé lówó oba fún omo rè tí ó fún un yìí. Léyìn èyí ni Òjélàdé wá padà sí ilé. Nígbà tí ó dé ilé, ó lo kí baálè ìlú rè. Ó fi èsà dúpé lówó gbogbo àwon tí ó bá a wálé láti ìgbà tí ó ti joyè yìí ni kò ti lo sí òde eré mó. Pèlú owó tí ó ti rí, ó di onísòwò pàtàkì. Baálè nìkan ni ó sì lówò jù ú lo ní ìlú yìí. Àwon omo isé rè tí ó ń lo sí òde ijó sì wá ń fi àbò jé e, ìyen nip é wón wá máa ń fún un ní nnkan tí wón bá ti ti òde idán dé.
[edit] Oju-iwe Keji
Àwon Òrò tí ó Ta kókó
Òkèrè: Erù tí a dì sínú aso tàbí àpò tí ó rí bànbà. Irú àpò yìí ni àwon omo èyìn eléégún máa ń di erù ìpidán won sí (ojú-ìwé 3)
Awórintúnrinro: Àwon alágbède ni wón máa ń lo òrò yìí fún nítorí pé àwon ni wón máa ń lu irin tàbí pé kí won na irin tí wón sì fi ń ro nnkan (ojú-ìwé 3)
Soró: Kí ènìyàn se oró, ìyen igi oró agogo (ojú-ìwé 4)
Esèntáyé: Yíye ohun tí omo tí a sèsè bí yóò gbé ilé ayé se wò. Esèntáyé tí wón yé wo ni wón fi mò pé isé eégún onídán ni Òjélàdé yóò se (ojú-ìwé 6)
Kerèé: Fààfàá ni èyí. Tí onídán bá n pa idán, yóò ta ení fààfàá yíká ara rè yóò sì máa wó gburugbu lo. Èyí ni wón fi máa ń so pé ó ń wó kerèé Eléyìí nì Òjélàdé se tí ó fi di òjòlá tí kò sì lè padà di ènìyàn mó. Bàbá rè Òjè Lárìnnàká ni ó se é láìmò pé omo òun ni.
Ewúsà: Òkété ni ó ń jé weúsà (ojú-ìwé 26)
Abá-òwú: Irú idán ken tí onídán fi máa ń di abá-òwú nì yí. Òjélàdé di abá-òwú nínú idán tí ó pa, ìyen nip é ó di òwú gulutu (ojú-ìwé 27)
Èrùùgàlè-kó-dìde: Idán kan nì yí tí onídán yóò ti máa ga lo sókè bí àwon omo èyìn rè bá ti ń korin fún-un (ojú-ìwé 27)
Olúwéré: Igi ìrókò ni ó ń jé báyìí (ojú-ìwé 34)
Arèsà: Oba ìlú Ìresà. Òjélàdé ti jó ní iwájú rè rí (ojú-ìwé 41)
Ìròré: Orísìí eye kan tí ó kéré nì yí (ojú-ìwé 41).
(1989), ‘Ìtàn Ìgbésí Ayé Láwuyì Ògúnníran’, nínú ‘Ìlò Èsà tàbí Iwì nínú Eégún Aláré.’, Àpilèko fún Oyè Bíeè, DALL, OAU, Ife. pp.24-25.
ÌTÀN ÌGBÉSÍ AYÉ ÒNKÒWÉ
A bí Láwuyì Ògúníran ní ojó Etì ojó kìíní osù Bélú (Novermber), odún 1935 ní abílé Akínkúnmi ní ekùn Ìròkò ní Ìjoba ìbílè Àríwá Akínyelé ní ìlú Ìbàdàn ní Ìpínlè Òyó. Orúko bàbá rè ni Samuel Àmòó Ògúnníran nígbà tí tí ìyá rè tó ti di olóògbé jé Julianah Oyáróhunké Àlàké Ògúnníran. Àgbè hán-ún ni bàbá Láwuyì nígbà tí ìyé rè jé onísòwò pépèpé. Inú èsìn kírítenì ni a bí Láwuyì sí. Èsìn kírítenì ni àwon ara ilé bàbá rè ń se nígbà tí àwon ará ilé ìyá rè jé elésìn kírítenì àti elésìn mùsùlùmí. Bàbá Láwuyì kóríra èsìn abòrìsà púpò. Láwuyì Ògúnníran kò tètè bèrè ilé-ìwé nítorí àsà owó tétí kò tétí tí àwon olùkó ìgbàanì máa ń wí. Nígbà tí Láwuyì pé omo odún mésàn-án ló bèrè ilé-ìwé alákòóbèrè ní ilé-èkó ìjo Elétò ní ìlú Fìdítì lékùn Òyó. Nígbà tí ó jáde nílé ìwé náà ó sisé fún ìgbà díè kí ó tó tún tè síwájú nínú èkó re nítorí pé owó já a ní tànmó-òn. Lásìkò yìí ni àmódi kolu òbí rè. Léyìn èyí Láwuyì Ògúníran kàwé abélé láti gbàwé èrí oníwèé méwàá (General Certification of Education). Láwuyì sisé ní ilé isé orísìírísìí kódà ó se akòwé kékeré lábé ilé-isé agbejórò (Lawyers Chambers). Ní osù Agemo ní odún 1962, Láwuyì dara pò mó àwon òsìsé ilé-ìtèwé “People’s Star Press Limited”. Ìgbà tí àwon ògá rè rí í pé Láwuyì Ògúnníran gbó èdè Yorùbá dáadáa wón sí i nípò lo sílé ìtèwé “Ìmólè Òwúrò” tí ó jé èka ìwé ìròhìn tí won ń tè jáde. Láwuyì ni ó ń mójútó àwon ìròhìn tó bá wolé, léhìn èyí Láwuyì di igbákejì olótùú ìròhìn kí ó tó tún wá di olótùú ìwé ìròhìn náà. Láwuyì ní ìwé èrí dípúlómà nínú isé akóròyìnjo (journalism). Lónìí, Láwuyì Ògúnníran ni Olótùú Òkin Olójà ti ilé-isé Túbòsún Oládàpò ń gbé jáde. Isé mìíràn tí Láwuyì tún ń se léyìn isé ìròhìn ni isé ònkòwé àti àgbè alároje. Láwuyì Ògúnníran ni ìyàwó ó sì ti bi àwon omo okùnrin àti obìnrin.
L.O. Adewole (2006), 'Eegun Alare', DALL, OAU, Ife, Nigeria.
[edit] Eégún Aláré
- Òjè Lárìnnàká àti Dásofúnjó
Òré tímótímó ni Òjè Lárìnnàká àti Dásofúnjó ní Òkèehò. Òjè Lárìnnàká lo pidán ní ìlú kan tí idán pípa ti tà. Ìdíwó ilé kò jé kí Dásofúnjó lo ní tirè. Aya Òjè Lárìnnàká tí ó ń jé Iyadunni ti lóyún ní àkókò yìí. Òjè Lárìnnàká dágbére fún àwon ebí rè àti fún Dásofúnjó. Dásofúnjó fún un ní ìwon nnkan tí ó ní tí ó lè fi se agbára kún èyí tí ó ní tí ó lè fi se agbára kún èyí tí òun náà ní. Ó dágbére fún ìyàwó rè ó sì sèlérí láti wá mú un kí ó tó bímo. Àwon omo èyìn rè gbé òkètè tí ohun èlò ìpidán wà nínú rè rù wón sì mú ònà ìrìnàjò won pòn. Ìyádùnní sìn wón sónà ó sì fi èsà ki oko rè. Èsà ni ewì tàbí iwì eégún. Nínú èsà tí Iyadunni fi ki oko rè ni a ti rí i pé Ìrèmògún, ará Ìlágbéde, eni tí ó máa ń lu irin tí ó ń tún un ún se ni Òjè Lárìnnàká. Ìyádùnní be oko rè nínú èsà yìí pé kí ó má gbàgbé òun nítorí pé lílo tí ó ń lo, kò dá ìgbà kankan tí òun yóò padà. Òjè Lárìnnàká náà fi èsà dá aya rè lóhùn pé ki òun náà má se gbàgbé òun. Dásofúnjó se ìtójú ìyàwó òré rè dáadáa. Títí tí ìyàwó fi bímo Òjè Lárìnnàká kò dé. Dásofúnjó àti àwon ebí ni ó so omo náà ní Ojélàdé fún esèntáyé omo yìí tí wón lo yè wò lódò babalawó odù òsá méjì ni ó go lójú ópón. Ese Ifá yìí so pé isé baba re ni omo yìí náà yóò se. Ifá ní ‘…Awo ààsàì goróyè’. Wón ní kí won rúbo. Awon ohun ebo sì ni eyelé mérin, àgbébò adìye mérin, obì gidi mérin àti òpá aso mérin. Wón rú ebo yìí. Léyìn odún méwàá tí ó ti bímo, Ìyádùnnì pinnu láti wá oko rè lo nítorí pé lójú rè, oko eni kú sàn ju oko eni nù lo àti pé wo ìsò dè mí kò lè dà bí onísò, ojú méwàá kò sì lè jo ojú eni. Ìyádùnní ní, lóòótó, Dásofúnjó tójú àwon síbè, àwon nílò láti wá Òjè Lárìnnàká lo. Léyìn odún kan ti Ìyádùnní àti omo rè ti kúrò ní ilé, wón pinnu láti dúró ní ìlú kan láti sisé díè nítorí pé owó ti ń tán lówó won. Wón ń gba àárù láti fi lè rí owó díè. Léyìn ìgbà tí wón ti se eléyìí fún ìgbà díè ni wón bá pinnu láti padà sílé nítorí pé bí iwájú kò bá seé lo, èyìn á á seé padà sí. Nígbà tí wón dé ilé, wón fi Òjélàdé sí òdò Dásofúnjó láti máa kó idán pípa. Dásofúnjó kó o ní isé yìí fún odún méwàá, ó sì yege. Léyìn ìgbà tí Òjélàdé ti kó isé tí ó yege tán ni ó pinnu láti wá ire tirè lo sí ìlú mìíràn nítorí pé “Erin kìí fon kí omo rè fon” Kí Òjélàdé tó lo, Dásofúnjó fún un ní omo rè, Ànséètù láti fi saya. Ní ojó kejì léyìn ìgbéyàwó ni Òjélàdé, ìyàwó rè àti àwon omo isé rè lo sí àjò. Nígbà tí wón dé ìlú kan, wón pinnu láti fi ibè se ibùdó kí wón sì máa ti ibè lo máa saré ní ìlú mìíràn. Tí Òjélàdé bá ń lo seré kì í mú ìyàwó rè dání nítorí pé kì í lo àlosùn. Nígbà tí ó se, Baálè ken pè é pé kí ó wá seré fún òun. Nígbà tí Òjélàdé ń lo jé Baálè yìí, ó mú ìyàwó rè dání. Ìrìn ojó méta ni ìlú yìí. Nígbà tí wón dé ibè, wón fi wón wò sí ilé Balógun ìlú yìí. Kí wón tó seré Òjélàdé àti ìyàwó rè jo lo kí àgbà eégún aláré kan ní ìlú yìí. Wón fún un ní èbùn. Òjélàdé so fún bàbá yìí pé òun wá saré ní ìlú náà ni. Bàbá yìí sì kí won dáadáa sùgbón gbàrà tí ó ti rí ìyàwó Òjélàdé ni ó tin í ifé rè gidi gan-an nítorí pé obìnrin tóí ó léwà púpò ni. Bàbá yìí be ìyàwó Òjélàdé pé kí ó fé òun sùgbón ìyàwó Òjélàdé kò jálè. Nígbà tí Ànséètù so fún oko rè nípa òrò yìí, oko rè lo ba bàbá yìí bàbá yìí sì so pé òun ti gbó. Ó ní òun kò mò pé ìyàwó rè ni. Kí ó tó di pé Òjélàdé be bàbá yìí kí ó tó gbà gan-an, bàbá yìí ti lérí pé òun lè pa Òjélàdé tí ìyàwó rè bá kò láti fé òun. Sùgbón gégé bí a se so sáájú, Òjélàdé be bàbá yìi, ó sì so pé òun gbà Òjélàdé. Ó se wón dá ojó eré. Ní ojó eré, wó kerèé ó ta òkìtì, ó di Òyìnbó, ó di olópàá ó sì di ekùn. Nígbà tí ó wó kerèé, ìyen nip é nígbà tí á di erè (ìyen òjòlá) ni Òjélàdé kò bá lè yí padà di ènìyàn mó. Oníbàtá ń so pé kí won la òjòlá kí won gbé omo ènìyàn jáde. Bí wón ti ń la òjòlá ni Òjélàdé ń so pé ara òun ni wón ń gé. Òjélàdé bèrè síí pèsà. Ó pè é dé ibi tí ó ti so pé “Lárínnàká, oko Iyadunni” ni bàbá òun. Bí ó ti pèsà dé ibí yìí ni bàbá kan bá jáde tí ó so pé omo òun ni Òjélàdé àti pé òun ti fi owó ara òun se ara òun. Ó ní òun ni òun se Òjélàdé nítorí pé òun fé gba ìyàwó rè. Ó tún se àlàyé síwájú sí i pé omo òun ni Òjélàdé àti pé ìyá rè ní oyún rè sínú ni òun kúrò ní ilé. Ó ní àdámò ni ó dà fún òun. Báyìí ni àwon èrò ìwòran se so ó di “Bàbá Àbámò”. Wón ní kí bàbá yìí lo mú èrò wá. Ó lo mú ìdó kan tí ìkóóde wà lénu rè wá ó sì gbé sìgìdì kan tí ó ń rin sin-in fún epo dání. Ó bèèrè fún èjè ewúré, Baálè wá a fún un. Ó ní kí won, ta kerèé yípo òjòlá náà, wón sì se béè. Ó dúró sí èyìn kerèé náà, ó fi èjè ewúré yí àdó oníkóóde náà. Ó mú àdó sí owó òtún, ó gbé sìgìdì sí owó òsì, ó sì bèrè síí pe ofò. Léyìn ofò yìí, Òjélàdé jáde kúrò nínú kerèé. Òjé Lárìnnàká fi èsà dúpé lówó Baálè wón sì korin pé, “E jé ká relé, ilé là ń lo; Àjò kan kò gbeni gbeni, kó dàbí ilé”. Wón padà sí ìlú won.
- Òjélàdé Omo Ojè Lárìnnàká
Léyìn ìgbà tí wón ti padà dé ilú tan ni Òjélàdé bá tún múra àtilo sí àjò mìíràn. Òjé Lárìnnàká ti dàgbà nígbà náà. Ó fi òpòlopò agbára rè han omo rè. Kò pé léyìn èyí tí ó fi kú. Omo rè se òkú rè fún osù méta Léyìn ìsìnkú yìí ni Òjélàdé wá múra ìrìnàjò rè. Nígbà tí ó dé ìlú kan tí ó ti fé saré, ó lo láti gbàyè lówó Baálè, oníyen sì fún un. Ní ojó eré, gbogbo ènìyàn pé jo láti wòran. Ní ojó yìí, Òjélàdé kò júbà kí ó tó bèrè eré gégé bí ó se máa ń se télè. Dípò tí Òjélàdé ìbá fi kókó júbà kí ó tó bèrè eré, ofò ni ó ń pè pé, “A kìí ráféfé mú…” A kò mò bóyá páàgùn ni ó ń dà á láàmu nítorí pé “ó gbékè lé agbára tí bàbá rè fún un”. Nínú èsà rè, ó ki Baálè ní “Ìkòyí omo erù Ofà” Nígbà tí Òjélàdé ki Baálè dé ibi tí ó ti so pé, “Èsó Ìkòyí, dá mi lóhùn ìwo ni ng ké sí” ni Baálè ni Baálè àti àwon ìyòyè bá fún Òjélàdé ní òpòlopò owó Baálè sì tún fún un ní Omobìnrin kan kí ó fi se aya. Òjélàdé fi èsà dúpé. Léyìn èyí ni ó bèrè síí pidán. Ibi tí Òjélàdé ti ń pidán ni àwon àgbà òjè tip é kí ló dé tí kò júbà kí ó tó bèrè eré. Orin àrífín ni Òjélàdé fi dá wo lóhùn pé, ‘Ìkòkò tó fojú deyìn, a fó…”. Àwon àgbà òjè yìí wá dan án. Ó di ònì, kò lè yí padà di ènìyàn mó. Nígbà tí Òjélàdé ti rí i pé òun kò lè yí padà di ènìyàn mó ni ó bá fi èsà so fún omo èyìn rè kan tí orúko rè ń jé Òjékúnlé pé kí ó lo bá òun mú èrò kan wá. Ó ní ‘O ó bá mi délé babami. Àdó kan ń be lájà a-mi-ló-ló-ló’. Àdó yìí ni Òjélàdé fi èsà so fún Òjékúnlé pé kí ó bá òun mú wá. Bí Òjékúnlé ti gbó ni ó ti mú ònà pòn láti lo mú àdó náà wa. Kí ó tó padà dé, òjó ti sú ó sì ti rò lé ònì lórí. Bí òjò yìí se rò lé e lórí ni ó bá wó wo inú omi lo. Etí omi yìí ni ó wà tí obìnrin kan wá sí etí odò yìí láti da eèrí nù. Bí ònì ti rí obìnrin yìí ni ó pe èsà sí i. Èrù ba obìnrin yìí bí ó se rí ònì tí ó ń pé èsà ó sì fi ìbèrùbojo da eèrí orí rè nù. Bí eèrí ti ó dànù yìí se kan ònì yìí lórí ni ó bá yí padà tí ó di ènìyàn, ìyen ni pé ó yí padà ó di Òjélàdé.
Òjélàdé wá tèlé obìnrin yìí lo sí ilé. Nígbà tí ó dé dé obìnrin yìí, ó se àlàye gbogbo ohun tí ó selè fún òun àti oko rè. Òko yìí ni ó sì fún un ní aso tí ó wò lo sí ilé. Ó tilè dé ilé sáájú àwon omo èyìn rè.
- Òjélàdé di Baálè Arèkú-Eégún
Èdìdì tí a mú di ìrókò olúwéré, ara ló fi san Báyìí ni ó rí fún Òjélàdé. Lékèé gbogbo ohun tí ó selè sí i, ń se ni òkìkí rè ń kàn sí i. Ó se, òkìkí rè kàn dé òdò Aláàfin. Aláàfin wá pè é pé kí ó wá fi iga gbága pèlú Dúdúyemí kí won fi lè yan eni tí yóò je ‘Baálè. Arèkú Eégún’. Ìyàwó rè kékeré tí Baálè fi ta á lóre bè é pé kí ó má lo sí ibi ìdíje yìí, kò gbà. Ó ní ijó ‘Ijó eégún kì í hun bàtá, àborúboyè kì í hun omo Awó. Ó ní isé bàbá òhun kò lè hun òun. Ìyàwó yìí bè é títí, ó fi orí so ó láyà, ó sì dákú. Nígbà tí ìyàwó yìí jí, Òjélàdé fi lókàn balè pé, ‘Odíderé kì í kú sóko ìwáje, béè ni omo inú odi kì í kú séyìn odì’. Nígbà tí òrò ti rí báyìí ni Ànséétu, ìyen ìyàwó tí ó dákú tí ó sì jí yìí bá so pé òun yóò bá won lo, Òjélàdé sì gbà fún un láti bá àwon lo sí ibi ìdíje náà. Èsà pípè, àti ijó nìkan ni wón fé fi se ìdíje. Òjélàdé kò jé kí iná èsìsì jó òun léèméjì, ìbà, ni ó kókó jú lójú agbo. Léyìn ti ó júbà tán, Dúdúyemí náà júbà. Léyìn èyí ni Òjélàdé wá fi èsà so àwon itú tí ó ti pa. Dúdúyemí náà fi èsà so itú tí òun náà ti pa. Ní ìparí èsà Dúdúyemí ni ó tip e Òjélàdé níjà pé kí ó fi èsà kí àwon Ológbùró. Òjélàdé kì wón. Ó so gbogbo ohun tí wón ń se àti èyí tí won kì í se. Ní ìparí, ó ní kí Dúdúyemí èsà sàlàyé eni tí ó kókó gbóyín Ògburò lo sódò tó pòsé. Dúdúyemí so pé ìyàwó Ológburò nì. Ó ní òun ni oyún inú rè jáde tí ó sì gbé rù ú ní odò. Nígbà tí obìnrin yìí dé ilé, ó so fún oko rè. Wón dífá, Ifá so pé okùnrin ni omo náà yóò jé àti pé ogun ni yóò máa jà. wón bí mo tán omo kò yéé sunkún nì wón bá gbé e jù sí, inú igbó. Nígbà tí won yóò fi padà dé ibè ní ojó kerìndínlógún, won kò bá omo mó. Omo ti bójú ogun lo. Bí Dúdúyemí ti dáhùn báyìí tán ni òun náà bèèrè ìbéèrè lówó Òjélàdé lórí Ológbùró ken náà. Òjélàdé sì dáhùn pé, ‘Oníkòyi lomo tí wón gbé jù sí gbàgede rè. Òun lÈsó Ìkòyí, omo erù Ofà’. Ogun tí omo bá lo, nígbà tí ó di odún kerìnlélógún tó tì bógun lo ni ó ránsé wálé pé kí won ó bá òun kí bàbá òun, ‘Omo a jáwé gbogbo pè é lóògùn’. Oríkì rè yí fi hàn pé onísèègùn ni. Dúdúyemí ní òótó ni Òjélàdé ń so. Òjélàdé náà wá ni kí Dúdúyemí bá òun dé, ‘Ilé Èdè Òdí Mode Ìresà’. Dúdúyemí náà fi èsà dá a lóhùn ó sì fí yé nip é isé epp síse ni isé won. Bí Dúdúyemí ti parí ni ó so fun Òjélàdé náà pé kí ó so ohun tí ó jé èèwò nílé ará Ìresà. Òjélàdé fi èsà se àlàyé ohun méta tí ó jé èèwò won. Won kì í fi kèké retí. Won kì í fi kèké ròfó. Won kì í fi agbada dínran je. Dúdúyemí náà tún gbà á lénu Òjélàdé léyìn ìgbà tí ó ti so pé òótó ni Òjálàdé ń so. Ó ní, Ìrù esin lòòsà nílé ara Ìresà’béè ni, ‘Ikin níí gbe ni’. Bí Dúdúyemí ti so eléyìí tán ní Òjélàdé wá bi í pé ta ló kókó rèkú eégún, ìyen ni pé tan i eégún àkókó ní ilé ayé. Dúdúyemí dáhùn pé Ológbojò ni, ìyen. ‘Èsà Ògbín, ará Ògbojò’. Duduyemí náà wá bi í pé ta ni ó ni eégún gan-an. Òjélàdé dáhùn pé Àrè Òjé Olójowòn ni ó ni ín kí Èsà Ògbín Ológbojò tó bá agbé e. Léyìn èyí ni Dúdúyemí wá ki èsà tí ó sì sàlàyé bí wón se ni kí àwon eégún lo ponmi wá tí àwon àgbààgbà méje òde Ògbín-ilé yóò mu lé kóókò tí wón sun je lóko lásìkò tí ìyàn mú. Eégún méfà ni ó kò láti lo pé tí àwon bá lo tán, won yóò gba àgó lówó àwon. Èkéje tí ó lo, òhún tí ó rí òkú eégún tí ó fó agbè mólè ni eégún tó jí. Léyìn tí Òjélàdé ti so pé Dúdúyemí yege tán ni Dúdúyemí wá bèèrè lówó re pé ibo ni Yorùbá ti sè. Òjélàdé sì dáhùn pé Ifè ni. Léyìn ìgbà tí Òjélàdé ti dáké tán tí àwon ènìyàn sì ti pàtéwó fún un tán ni obá bá pa á láse pé kí wón pa ìtàn síso tì kí won wá ohun mìíràn se. Bí oba ti so eléyìí tán ni Dúdúyemí bá ki enu bo èsà ó sì so bí Òjélàdé se di ere àti bí ó se di òòni tí ó jé pé obìnrin kan tí ó lo da ògì nù ni ó jé kí ó yí padà di ènìyàn láti ipò òònì tí ó wà. Léyìn èyí ni Òjélàdé náà wá fi èsà so pé se kí òun náà wí o, sé kò níí sí nnkan. Oba, Dúdúyemí àti àwon ènìyàn ní kí ó máa wí. Bí wón ti gbà á láyè yìí ni Òjélàdé wá fi èsà wí pé Àmòó tí ó jé bàbá “Dúdúyemí di mààlúù ó sì wogbó lo. Ó ní nítorí ìdí èyí ni Dúdúyemí se ń hùwà bí eranko. Òrò yìí dun Dúdúyèmí. Àwon ènìyàn ń fi se yèyé wón sì ń fi owó fo Òjélàdé lórí. Dúdúyemí wá yo ìwo kan ní àpò, ó pe ofò kélékélé sí i ó sì so fún Òjélàdé pé kí ó tún ìtàn rè pa. Bí Òjélàdé ti fé máa pèsà báyìí, gbígbó ni ó ń gbó bí ajá. Ìyàwó rè, Ànséétù rí ohun tí ó ń se é, ó wá lo sí ibi òkètè oko rè ó sì mú oògùn kan jáde, ó bèrè síí pofò. Kò pé léyìn tí ó ti ń pofò yìí tí oko rè bèrè síí pèsà ó sì fi ewà ìyàwó rè wé ti Sábárúmó, ìyen fúlàní. Léyìn ìgbà tí Òjélàdé ti sojí yii ni ó wá so fún Dúdúyemí pé kí ó bá òun ki ‘Ìyèrú Òkún Olófàmojo nílé Olálomí’, ìyen oríkì ìyá oba. Bí Dúdúyemí se nì kí òun máa sòrò báyìí ikó ni ó ń hú tí èjè sì ń dà lénu rè. Gbogbo oògùn tí ìyàwó àti àwon omo èyìn rè se fún un kò sisé. Lékèe gbogbo ohun tí ó ń selè yìí orin ni Òjélàdé àti ìyàwó rè ń ko tí wón sì ń jó tí wón ń korin tí gbogbo ènìyàn sì ń wòran won. Nígbà tí ó se, obá so fún Òjélàdé pé kí ó tú Dúdúyemí sílè. Òjélàdé se bí oba ti wí. Oba wá so pé Òjélàdé ni ó yege ó sì fi je Baálè arèkú eégún. Dúdúyemí lo bá Òjélàdé ní ibi tí ó ti ń jó. Oba ní kí Dúdúyemí júbà fún Òjélàdé gégé bíi ‘Baálè arèkú eégún. Dúdúyemí sì se béè’. Léyìn èyí ni Òjélàdé wá fi èsà ki Ìyèrú Òkín Olófàmojo. Bí ó ti se èyí tán ni oba bá fi omo rè kan ta á lóre kí ó fi saya. Òjélàdé fi èsà dúpé lówó oba fún omo rè tí ó fún un yìí. Léyìn èyí ni Òjélàdé wá padà sí ilé. Nígbà tí ó dé ilé, ó lo kí baálè ìlú rè. Ó fi èsà dúpé lówó gbogbo àwon tí ó bá a wálé láti ìgbà tí ó ti joyè yìí ni kò ti lo sí òde eré mó. Pèlú owó tí ó ti rí, ó di onísòwò pàtàkì. Baálè nìkan ni ó sì lówò jù ú lo ní ìlú yìí. Àwon omo isé rè tí ó ń lo sí òde ijó sì wá ń fi àbò jé e, ìyen nip é wón wá máa ń fún un ní nnkan tí wón bá ti ti òde idán dé.
- Àwon Òrò tí ó Ta kókó
Òkèrè: Erù tí a dì sínú aso tàbí àpò tí ó rí bànbà. Irú àpò yìí ni àwon omo èyìn eléégún máa ń di erù ìpidán won sí (ojú-ìwé 3)
Awórintúnrinro: Àwon alágbède ni wón máa ń lo òrò yìí fún nítorí pé àwon ni wón máa ń lu irin tàbí pé kí won na irin tí wón sì fi ń ro nnkan (ojú-ìwé 3)
Soró: Kí ènìyàn se oró, ìyen igi oró agogo (ojú-ìwé 4)
Esèntáyé: Yíye ohun tí omo tí a sèsè bí yóò gbé ilé ayé se wò. Esèntáyé tí wón yé wo ni wón fi mò pé isé eégún onídán ni Òjélàdé yóò se (ojú-ìwé 6)
Kerèé: Fààfàá ni èyí. Tí onídán bá n pa idán, yóò ta ení fààfàá yíká ara rè yóò sì máa wó gburugbu lo. Èyí ni wón fi máa ń so pé ó ń wó kerèé Eléyìí nì Òjélàdé se tí ó fi di òjòlá tí kò sì lè padà di ènìyàn mó. Bàbá rè Òjè Lárìnnàká ni ó se é láìmò pé omo òun ni.
Ewúsà: Òkété ni ó ń jé weúsà (ojú-ìwé 26)
Abá-òwú: Irú idán ken tí onídán fi máa ń di abá-òwú nì yí. Òjélàdé di abá-òwú nínú idán tí ó pa, ìyen nip é ó di òwú gulutu (ojú-ìwé 27)
Èrùùgàlè-kó-dìde: Idán kan nì yí tí onídán yóò ti máa ga lo sókè bí àwon omo èyìn rè bá ti ń korin fún-un (ojú-ìwé 27)
Olúwéré: Igi ìrókò ni ó ń jé báyìí (ojú-ìwé 34)
Arèsà: Oba ìlú Ìresà. Òjélàdé ti jó ní iwájú rè rí (ojú-ìwé 41)
Ìròré: Orísìí eye kan tí ó kéré nì yí (ojú-ìwé 41).