Asenibanidaro
From Wikipedia
Asenibanidaro
Akinlade
Kólá Akínlàdé 91982), Asenibánidárò. Ìbàdàn, Nigeria: Heinemann Educational Books (Nig.) Ltd. ISBN: 978 129 217 2. Ojú-ìwé 71.
ÌTÓWÒ
Wón se àìsùn òkú ìyá Adégùn moju ni apoti tí owó wà nínú rè bá sonù, ó sonù towítowó! Ipayà wá dé bá Adégún; ó ku àádota náira ti yoo san fun oloti, awon abánisèye sì ti mu oti tán, oloti fé gbowó, apoti sì sonù towótowo! Èèmò; ogun ń lé won bò, odò kún! Opélopé Adeogun òré rè ló fún olóti ni àádota náira, oun ni kò jé ki Adegun sèsín. Ta ní jí apoti omo-olókùú gbé towótowo? A lè pe ni wá jebo kò sì di òràn? Àkanbi agbèrò wà nibi àìsùn naa, oun sì jé “firì nídìí òké, a lo k’ólóhun kígbe.” Oun ni wón koko fura sí. Wón sì tún fura si Arìyìíbí awakò. Akin Olusina, ògbóntagí òtelèmúyé, wá bó sénu isé pereu. Èrí tó koko ri na ìka èsùn sí Níran ati Olúdé, awon mejeeji wonyi sì jé awakò pelú. Sùgbón ohun tó wà léhìn òfà ju òje lo. Jé kí a tele àgbà òtelèmúyé wa, Akin Olusina, bó ti n fi ogbón isé ati òpò làákàyè topa òrò náà títí owó fi te òkúùgbé asenibánidárò.