Oju Odu Mereerindinlogun
From Wikipedia
Oju Odu Mereerindinlogun
Awon Oju Odu Mereerindinlogun
Odu
Odu Ifa
Wande Abimbola
Wande Abímbólá (1977), Àwon Ojú Odù Mérèèrìndínlógun. Ìbàdàn, Nigeria. University Press Plc, 160pp.
Ìwé yìí jé àkójopò ese Ifá tí amú láti inú àwon Ojú Odù (Olójà) Mérèèrìndínlógún. A mú ese Ifá méjo-méjo láti inú Odù kòòkan bèrè láti inú Èjì Ogbè títí ti ó fi kan Òfún (Òràngún) méjì.
Ìyàtò tí ó wà nínú ìwé yìí àti àwon ìwé Ifá àti ewì àdáyébá mìíràn ni pé a se àlàyé ese Ifá kòòkan tí ń be nínú ìwé yìí leseese. A se èyí nítorí pé a ti se àkíyèsí wí pé àwon ese Ifá wònyí kì í yé àwon akékòó (àti olùkó náà dáadáa nígbà tí won bá ń kà wón. Èdè àtayébáyé ni èdè Òrúnmìlà. Nítorí náà kò ya ‘ni lénu wí pé èdè ifá kì í tètè yé ògbèrì. Ìdí nìyí tí a fi se àlàyé sókísókí lórí ese kòòkan. Fún eni ti ó bá ní òye, tí ó sì ní ìfé sí ese Ifá, a lérò pé àlàyé wònyí ó jèé ìlànà pàtàkì nígbà tí ó ba ń ka ìwé yìí finífiní.
Ní ìbèrè ìwé yìí, a se àlàyé nípa ohun tí Ifá jé gégé bí òrìsà àti ewì àdáyébá Yorùbá. A lérò wí pé àlàyé yìí náà ó ran àwon ònkàwé wa lówó láti mo ipò ti Ifá kó nínú ogbón, ìmò àti ìrírí omo Yorùbá.