Isan-Ekiti

From Wikipedia

Isan-Ekiti

A.O. Ademiluyi

ÌLÚ ISÀN-ÈKÌTÌ láti owó A.O. Adémilúyì, UOA, Adó-Èkìtì, Nigeria

Ìlú Isàn wà ní apá, ìlà-oòrùn ìpínlè Èkìtì ní Ìjoba Ìbílè Oyé. Kìlómítà méjìdínláàdóta ni Isàn se si Adó-Èkìtì. Ekù méjo ni Isàn pín sí. Àwon náà ni Òkesàn, Àdisà, Igbómojì, Ìrèfin, ogilóló, Ìlalè, Ìlúsàjùmú àti Sùrúlérè.

Ìwádìí tí a se fi yé wa pé bí ó tilè jé pé èkan èdè kan náà ni won ń so ni ekùn méjèèjo yìí, márùn-ún lára méjo yìí ni èdè wón bára mu régírégí. Sùgbón àwon ìyàtò wònyí kò fi béè hàn sí eni tí kì í se omobíbí Isàn-Èkìtì.

ÌTÀN ÌSÈDÁLÈ ÌLÚ ISÀN

Ògúntúyì (1979 : 94) fi yé wa pé Ilé-Ifè ni àwon ènìyàn Isàn ti wá si ibi tí wón wà lónìí, àti pé a kò mo orúko Onísàn tí ó ko won wá láti Ìlú Ifè. Ó sàlàyé pé Ogun ti kó won lérú lópò ìgbà kí won tó tèdó sí ibi tí wón wà lónìí.

Nínú àbò ìwádìí wa bákan náà, a gbó pé Ilé Ifè ni àwon ènìyàn Isàn ti wá. Èdè àiyedè tí ó bé sílè ní Ilé-Ifè ni ó mú won kúrò níbè láti wá tèdó sí ibi tí wón wà lónìí. Nígbà tí wón kókó parapò sí ibi tí wón wà yìí, èdè àìyedè yìí tún bèrè tí ó jé pé wón tún ni láti túkà. Àwon kan yà sí òkè-oko, àwon kan lo sí Igbó Alárùà, béè ni àwon mìíràn lo sí Ìpólé.

Àsìkò tí ogun Fúlàní dé tí ó ń kó àwon ènìyàn lérú ni àwon ènìyàn Isàn wa ronú pé ó ye kí wón parí èdè-àìyedè yìí kí wón sì parapò láti ségun àwon Fúlàní náà. Sísàn tí wón wá sàn papò láti onírúurú ibi tí wón yapa sí ni a fi ń pè won ni Isàn títí di oní.

Àkíyèsí: A yo isé yìí láti inú àpìlèko Émeè A.O. Adémilúyì.