Orisa Agbadii
From Wikipedia
Agbadii
G.A. Ademola
G.A. Adémólá (1979), ÌTÀN ÒRÌSÀ AGBÁDÌÍ’, DALL, OAU, Ifè, Nigeria
Ìtàn so fún wa pé okùnrin ni Agbádìí nígbà ayé rè. Isé ode ni ó sì ń se nígbà náà. Gégé bí ìwádìí ti so fún wa, apó, ofà àti orun ni ó fi ń se isé ode, èyí ni wón fi máa ń kì í báyìí:
Ode Ìrenà kéé kápó òjé
Ode dídú kéé tàrun
Ìwádìí so fún un pé Obàtálá kó àwon òrìsà kun móra láti bá Olófin Oòduà jagun nígbà tí ó ti ìkòlé òrun bò wá sí tayé. Nítorí ó so pé Olófín Oòduà jí Àse tí Olódùmarè gbé fún òun láti lo fi sèdá ayé gbé.4 Níwòn ìgbà tí Agbádìí ti jé òrìsà funfun, òkun nínú àwon tí babaláwo Babalolá Fátóògùn pè ní èyà Obatálá nítorí wón jé omo rè, Agbádìí ní láti jé òkan nínú àwon ode tí ó ran Obàtálá lówó.
Nípa òríkì rè òkè yìí, a rí Agbádìí gégé bí òrìsà àwon omo Arénà, tí wón wà ní ìta ìronà ní ìlú ìmèsí-Ilé. Ènìyàn dúdú sì ni Agbádìí. Ìtàn so fún wa pé baba ńlá àwon omo Arénà tí ó ń jé Òdunmorun ni ó gbé Òrìsà yìí wá sí ìlú Ìmèsí-Ilé láti apá ilè Olújìí. Baba ńlá won yìí jé òkan nínú àwon méta àkókó tí ó dó sí ìlú Ìmèsí – Ilé.5 Kò ní sàìyà wá lénu pé obìnrin ni àwòrò fún òrìsà Agbádìí tí ó jé okùnrin. Ìwádìí so fún wa pé àwòrò tí ó wà níbè yìí ni ó jé èkejì, àwon méjèèjì ni ó jé obìnrin. Ohun tí a sì gbó nínú ìwádìí ni pé òrìsà yìí ni ó máa ń yan àwòrò rè nínú ìdílé yìí nípa fífi àmi sí i lára òrun wá. Gbogbo àwon tí ó ní àmi òrìsà yìí lára, tí wón sì ti jé àwòrò ni wón jé obìnrin. Bóyá ìgbà tún le yí padà kí òrìsà yìí tún yan okùnrin gégé bí àwòrò rè. Ohun tí ó se pàtàkì ni pé bí obìnrín ti ń se àwòrò òrìsà yìí náà ni okùnrin le se é, bí ó bá sá ti jé eni tí òrìsà yìí yàn láti ínú oyún wá ni. Àmì sì wà láti mo eni tí òrìsà yìí yàn.6 ‘Olómiítù’ ni a máa ń so àwon omo tí òrìsà Agbádìí bá fún nì. Nígbà mìíran a máa ń so wón ní orúko mó ode gégé bí Odégbèmí
Òrìsà tó fún ni lómo là ń pè
Òrìsà tó fún ni lómo là ń pòkìkí
N ó moo pòkìkí re nítorí ‘Lomi’
Gégé bí ìwádìí tún tí mú wa mò, a gbó wí pé kì í se Ògún nìkan ni Òrìsà Ode, Ògún kààn jé olú nínú won ni. Nínú àwon tí ó tèlé e ni, Òrìsà oko, Erinlè, Àgbàndada, Àbadi7, Alámò, Owáálá, àti Òni. A mò pé odo ni àwon wònyí nítorí gbogbo àwon tí ń sìn wón ní ń jé orúko mó “ode”8. Ìtàn yìí sì tún so fún wa pó orísirísi isé ni Òrìsà kòòkan máa ń mò, a tilè gbó pé àwon òrìsà wònyí ti máa ń, tòrun wá máa ń sísé eja pípa láyé kí won tó sèdá ilè sí orí omi yìí.
Bí a ti mò, orísìírísìí isé ni ó sí sílè fún ode láti se, láàrin isé béè ni Ogun jíjà, óògùn síse, èyí kò so pé babaláwo ni wón o. Nípa báyìí won a máa somo fún àgàn. Ìmo won nípa isé ode yìí máa ń mu won la ònà láti ìlú kan sí èkejì nínú igbó. Èyí jé pé won ń pèsè ònà fún ará ìlú láti rìn. Nípa lílo sínú igbó nígbà gbogbo, wón máa ń jé amí fún oba àti ará ìlú. Àwon ni ó kókó náa ń mo ìgbà tí aná ìlú kan bá ń féé gbógun ti ìlú kejì, tàbí nígbà tí ìlú kan bá ń kojá ààlà rè wo ilè ìlú kejì. Bí èyí bá selè, àwon ni yíò wá samí fóba.
Etí oba bá sì dé àwon ode ní ń jagun láti dáàbò bo ìlú won, lára ìdílè àwon tí ń jagun ni Èsó wà.9 Nípa isé won náà, wón tún ní ànfààní láti te ìlú dó. Léhìn èyí, àwon ode tún máa ń pèsè eran fún ará ìlú láti je. Níwòn ìgbà tí Agbádìí sì ti jé ode nígbà ayé rè, kò sí òkan nínú isé yìí tí kò tin í fi ara rè hàn, ní pàtàkì, fífún àgàn lómo.
Léhìn ìgbà tí Agbádìí sì ti di Òrìsà yìí, àwon ènìyàn ní ìgbàgbó pé gbogbo agbára tí ó ní nígbà ayé rè ni ó sì ń lò fún won nígbàkígbà tí wón bá kó pè é. Bóyá ìdí níyí tí ó fi jé pé gbogbo oba tí ó bá je ní ìlú Ìrèsí-Ilé ni ó ní láti máa bo òrìsà yìí, ó sì ní láti lo sí ìdílé ibi tí wón ti ń bo Òrìsà yìí láti gba Adé rè, nítorí oba ń fé kí ó máa dáabò bo ìlú fún òun.
Nígbò báa sorò rè lódún
Oba á ba sé.
Áá fun lóbì, áá fun látayé10
Àkíyèsí: “Áá fun lóbì, áá fun látayé” túmò sí “Yóó fún un lóbì yóó fún un látaare.