Ife

From Wikipedia

Ife

C.O. Odejobi

Ifè láti owó C.O. Odéjobí, DALL, OAU, IFÈ Nigeria.

Òpòlopò àwon asiwájú nínú ìmò ni wón ti so ìtàn ìsèdálè Ifè. Bákan náà Johnson1, Gugler, àti Flanagan2 tó fi mó Fásogbón3 so ìtàn Ifè nínú isé won. Gégé bí ìwádìí, ònà méjì ni ìtàn Ifè pín sí. Èkíní je mó ìgbàgbó nípa pé láti ìpilèsè ni Ifè ti wà. Ìtàn kejì ni èyí tí ó sun jáde láti ara Odùduwà1. Ìtàn àkókó ni ti Ifè Oòdáyé2 Ìtàn ìwásè náà so pé Olódùmarè pe àwon Òrìsà láti lo wo ilé ayé wá nígbà ti ó fé dá ayé. Ó fún won ní èèpè tí ó wà nínú ìkarahun ìgbín, adìe elésè márùn-ún, àti òga. Nígbà tí wón dé ilé ayé, wón rí i pé omi ní ó kún gbogbo rè, àwon òrìsà da eèpè tí Ooódùmarè fún won sí orí omi náà, adìe elésè márùn-ún sì tàn án. Bí adìe elésè márùn-ún se ń tan ilè yìí béè ni ilè ń fè sí i èyí náà ló bí orúko Ifè.

Ìtàn kejì ni pé láti ìlú mékà ni Lámurúdu tí ó jé baba Odùduwà ti wá sí Ifè. Ogun Mohammed tí ó jà láàrin kèfèrí àti mùsùlùmí ìgbà náà ló ká Lámúrúdu mó. Èyí ti Lámurúdu ìbá fi gbà, ó fi ìlú Mékà sílè, ó sì te Ifè dó.3 Léyìn ikú Lámurúdu ni Odùduwà gba Ipò. Ilé Òrúntó ti wà ní Ifè kí Lámurúdu tó dé. àwon ará ilé Òrúntó ni ó gba Lámurúdu àti Odùduwà ní àlejò4. Àwon ará ilé Òrúntó gbà fún Odùduwà láti jé olórì won nítorì pé alágbára ni.

Ìtàn ti akoko yìí ló so bí Olódùmarè se ran àwon orisa láti wá dá ayé. Léyìn tí àwon orisa dá ayé tan, ti wón sì ti ń gbé ibè ni Odùduwà tó wá sí Ile-Ifè láti ìlú Meka. Abénà ìmò itan kejì yìí tilè fi kún òrò rè pé Lámurúdu àti Odùduwà bá àwon kan ni Ilé-Ifè nígbà ti wón dé Ifè. Ohun tí èyí èyí ń fi yé wa nip é nibi tí ìtàn akoko parí si ni ìtàn kejì ti bere.

Àkíyèsí: A yo isé yìí láti inú àpilèko Émeè C.O. Odéjobí .