Eegun
From Wikipedia
Eegun
B.A. Akinduro
B.A. Akíndúró (1977), Bí Eégún se Bèrè’, DALL OAU, Ifè Nigeria
Ìtàn tí n ó so nípa bí eégún se délé ayé yìí, mo gbó o láti enu baba babaà mi ni kí ó tó di pé wón jé ìpè Olódùmarà ní nǹkan bí odún méwàá séhìn. Ìdí pàtàkì tí ó jé kí n fi ara mó ìtàn náà ni pé ó fi ara jo ìtàn tí mo kà lórí nǹkan kan náà ìwé Òmòwé J.A. Adédèjì1. Ìdí mìíràn tí ó jé kí n fi ara ḿó ìtàn náà yàtò sí òmíràn nip é enu àwon tí mo se ìwadìí lówó won kò kò lóŕi òrò náà. Ó dà bí eni pé olúkálukú ni ó fé fi bu iyi kún ìlú tirè pé ní ìĺú tòun ni awo Iségún ti bèrè. Ògbéni Táyélolú Sásálolá tí ó ń gbé ni ìlú Oǹd́ó tilè so f́ún mi pé ní ìlú Òfà ni Eégun ti sè. Nígbà tí mo sì fi òrò wá a lénu wò, mo rí i pé omo Òfà ni baba rè. Omo Iwékosé tún so fún mí pé ó dá òun lójú pé ní ìlú Òkè-igbó lébàá Oǹd́ó ni Eégún ti kókó bèrè.
Nínú Ìdàrúdàpò yìí ni mo wá rò ó pé bí ènìyàn bá féé mo òtító tí ó wà nídìí òrò náà, àfi bí ènìyàn bá to Ifá lo nítorí pé If́a kò ní í gbè séhìn enìkéni. Orísìí ìtàn méjì ni mo sì wá rí ńinú Ifá. Sùgbón ìtàn kéjì ni mo fi ara mó. Ìdí tí mo sì se fi ara mó on náà nip é ó jo ìtàn tí mo ti gbó lénu baba babaà mi. Èyí nìkan kó: mo fi ara mó
1. Adédèjì J.A. The Alárìnjó Theatre: The Study of a Yorúbà theatrical Art form its Origin to the Present Times. Ph.D. Thesis (University of Ibadan), 1969, pp. 20-90.
Ìtàn kejì yìí nítorí pé ó tún là wá lóye lórí bí orúko náà, “Eégún”, ti se bèrè.
Ìtàn àkókó yìí wà nínú Odù Èjì ogbè, Esè Èkejì. Ìbéjì ni wón fi Eegún bí. Òkán kú èkejì sì wà láàyè. Èyí tí ó wà láàyè si wá ́n sunkún sá. Wón wá dógbón, wón dáso Eégún. Wón mú èyí tí ó wà enìkan lórí. Eni tí ó gbé Eégún náà ń pe eni tí ó wà láàyè pé: “Mó tí ì wá o,
Ìhín ò rò o ò.”
Ese Ifá náà lo báyìí:
“Ńí ojó tí Éégún dé ayé,
Ìbejì ni wón bí i.
Òkan kú, òkan wà láàyè.
Èyí tí ó wà láàyè wáá sunkún títí,
Ni wón bá dógbón,
Wón dáso Eégún.
Wón mú èyí tí ó wà láàyè lo sínú igbó.
Wón gbé aso Eégún náà bo enìkan lórí.
Eni tí ó gbé Eégún náà ń pé
Èyí tí ó wà láàyè pé:
Mo tíì wá o,
Ìh́in ò rò o ó.
Èyí tí ó wà láàyè bèrè síí sunkún,
1. Abimbóla Wandé, Awon Odù Mérèèrìndímlógún. (memio), pp. 3-4.
Eégún náà yára wo inú igbó lo.
Aso tí a dà bo alààyè lórí
Ni à ń pè ní èkú Eégún.
Èkú ayé o,
Èkú òrun,
N à ń pè ní èjìgbèdè èkù.”
Ìtàn ke jì wà nínú ìwé Òmówé J.A. Adédèjì tí mo ti tóka sí télè. Ńińu Odù Òwónrínsè ni ó wà. Ìtàn náà lo báyìí: Nígbà TÌ Òwónrín tí ó ń gbé ní Ìsányín dolóògbé, àwon omo rè métèèta - Arúkú, Arùḱu àti Aròḱu-roja-má-tà kò ní owó lówó lati fi se òkú bàbáa won. Ìrònú òràn náà pò dé bi pé èyí Arúkú tí ó jé ègbón fún gbogbo won fi ìlú sílè. Béè ni èyí àtèlé rè, Arùkú, mú ìmòràn wá pé kí àwon ó ta òkú náà1. Èyí àbúrò won, Aròkú-roja-má-tà, bá kiri òkú náà lo. Sùgbón nígbà tí ó ti kiri fún ìgbà díè tí kò ti rí eni ra òkú náà ni ó ti sú u, ó sì wó òkú náà jùnù sínú igbó; ó bá tirè lo. Léhìn ìgbà díè, èyí ègbón di baálé ilé, ó sì gba ipò bàbá rè gégé bí Ológbìín. Gégé bí ipò rè òun ni ó sì wá di Ológbo2. Bí ó tilè jé pé abuké ni, Aláàfin fún un ní ìyàwó kan, eni tí orúko rè ń jé Ìyá Mòsè. Sùgbón fún òpòlopò od́un, Mòsè kò gbó mokòó
1. Won a máa ta òkú láyé àtijó fún àwon olóògùn tí won fé lo èya ara òkú náà.
2. Akígbe tí ́o sì máa ń ru òpá oyè Aláàfin. rárá; ó kàn ń fowó osùn nu ògiri gbígbe ni. Èyí ni ó mú kí oko rè Ológbìín to Òrúnmìlà lo. Nígbà tí ó débà tí ó débè, ó ńi “emi ló dé tí ìyàwó òun fi rómo léhìn adìe tó bú púrú sékún?” Òrúnmìlà sì so fún un pé àfi tí ó bá lè se èye ìkehìn fún baba rè tí ó ti kú kí ìyàwó rè ó tó lè bímo.
Ní àkókò yìí, Ìyá Mòsè ti ló sódò Amúsan láti lo se ìwádìí ohun tí ó fa sábàbí. Bí Ìyá Mòsè ti ń bò láti odò Asà níjò kan ni elégbèdè kan jáde sí i láti inu igbó tí ó sì bá a lòpò. Béè ni Ìyá Mosè se béè lóyún. Mòsè kò sì lè jéwò bí ó se lóyún fún oko rè. Ó sì fòn ón ó di òdò Olópondà tí ó jé ègbón Ìyá Mòsè. Níbè ni ó ti bí ìjímèrè. Ìtìjú a máa pa gbajúmò. Nígbà tíìtìjú pò fún Mòsè, ó tún fon ón, ó di òdò oko rè. Bí ó sì ti ń lo lónà ni ó ju ìjímèrè sínú igbó. Sé oko rè kò kúkú mo nnkan tí ó bí. Nígbà tí ó dijò keje ni Ato tí ó jé ìyàwó Ògògó tí ó jé omo Ìgbórí rí ìjímèrè igbó. Ní àkókò tí a ń wí yìí. Ológbìín ti gbó gbogbo ohun tí ó selè. Ó ti lo sí òdò Òrúnmìlà, Ifá sì ti so fún un pé sùúrù lebo. Ifá ní kí Ológbìín máa tójú abàmì omo náà, sùgbón kí ó tún se èye ìkohìn fún baba rè nìpa lílo sí igbó níbi tí wón ti rí abàmì omo náà láti lo ya eégún baba rè. Àwon ohun tí Ifá pa láse ètùtù náà ni egbèrin àkàrà, egbèrin èko, egbèrin pàsán àti òpòlópò emu. Igbó tí won ti se ètùtù náà ni a mò sí igbó ìgbàlè di òní olónìí.
Aláràn-án òfí tí ó jé ìyekan Ológbìín ni ó gbé aso òdòdó tí baba Ológbìín tí ó ti kú ń lò nígbà ayé rè bora, tí ó sì tún gbé abàmì omo náà pòn séhìn, tí ó sì ń jó bò wá sí àárín ìlú láti inú igbó náà pèlú ìlù àti òpòlopò ènìyàn léhìn rè. Ológbìín ti fi lò télè pé òun yóò se èye ìkehìn fún baba òun tí ó ti kú nítorí náà nígbà tí wón rí Aláràn-án Òrí nínú aso òdòdó, wón se bí Ológbìín tí ó ti kú ni, pàápàá tí abàmì omo tí ó pòn dà bí iké èhìn rè. Àwon ènìyàn ń sún mó on láti wò ó dáadáa sùgbón pàsán tí wón fi ń nà wón kò jé kí won sì wo ilé baba Ológbìín tí ó ti kú lo. Bí àwon ènìyàn ti ń wò ó ni wón wí pé:
“E wo begun eni tó kú ti gún tó!
Egungun náà gún lóòótó!
Egungún gún! Egungún gún!”
Báyìí ni àrá òrun náà se se káàkiri ìlú tí ó sì ń súre fún àwon ènìyàn. Nígbà tí ó sì se ó wo káà lo. Wón sì pe Ato kí ó máa tójú abàmì omo náà. Wón sì ń pe abàmì omo náà níOlúgbèré Àgan. Nínú káà yìí ni Ògògó tí ó jé oko Ato, ti ń wo omo náà nígbàkúùgbà. Àwon ènìyàn inú ilé a sì máa pe Ògògó ní Alàgbòó-wá1. Alágbòó-wá yìí ni ó sì di Alágbàá (baba Maríwo) títí di òní olónìí. Odù Òwónrínsè náà nìyí:
“Arúkí,
Arùkú,
Aròkú-rojà-má-tà.
Òkú tá a gbé rojà tí ò tà;
1. Ìtumò èyí ni eni tí ó gbó tí ó wá.
La gbé so sígbó.
Òun la tún gbé wálé,
Tá a daso bò,
Tá a ń pè léégún.
A dÌfá fún Òwónrín Ìsányín
Tó kú tí àwon omo rè
Kò rówó sin ín.1
Bí a bá sì tún wo oríkì eégún, òrò nípa bí eégún se kókó bèrè yóò túbò tún yé wa sí i. Gégé bí a ti mò, oríkì ni òrò tí ó júwe ìwà, ìse2 àti Ìtàn ìbí àwon òrìsà, ènìyàn àti àwon nnkan mìíràn. Oríkì Egúngún náà lo báyìí:
“Egúngún Ajùwón,
Lùkùlùkù gbúù-gbúù!
A-rágò gbálè,
Egúngún kìkì egungun
T’Ògògó!
Òkú yìí gbérí!
Eni ará kan
Tí ń jí jó awo.
1. Adédèjì, J.A. The Alárinjó Theatre. The Study of a Yorùbá theatrical Art from its Origin to the Present Times. Ph.D. Thesis (University of Ibadan 1969). Pp. 60-88.
2. Babalolá, A Àwon Oríkì Orílè, pp. 11.
Òsòràn lokùn ń dè lÁgburè.
Ìgbà tí n kò sòràn okùn,
Kí le mókùn so mí lápá sí?
Omo kéké mo sá,
Mo mú sèwe lÁgburè.
Gònbò ni mo wà,
Mo mú sèwe nIgbórí1
‘Torí Ìgbórí mi lÒyó Mòko.
Baba Arúkú,
Baba Arùkú,
Baba Aròkú-rojà-ma-tà.
Òkú tá a gbé rojà
Tá ò tà,
Òun la dáso fún
Tá à ń pè léégún.
Ikú ‘i lÓdò.
Omo atòkú jeun,
Omo atáyé solè nÍgbàlè.
Baba Ato kékeré
A-benu wéjewéje.2
Báyìí a ti mò bí eégún se kókó dé inú ayé nígbà ìwásè.
1. Àwon Tápà ló ń jé béè.
2. Adédèjì, J.A. The Alárìnjó Theatre; (The Study of a Yorùbá Theatrical Art from its Origin to the Present Times.) Ph.D. Thesis (University of Ibadan 1969). Pp. 60.88.
Sùgbón láyé òde òní ń kó? Báwo ni a se ń ‘sé’ eégún? Ó sòroó so pàtó pé kò níí sí ìyàtò díè láti ìlú dé ìlú lórí òrò bí a se ń ‘sé’ eégún. Sùgbón bí ìyàtò kàn tilè wà náà, kò pò rárá. Mo léèrò wí pé àwon obìnrin kò ní í mo ìdí abájo. Obìn in a sì máa mo awo, sùgbón bí wón bá tilè mo ón, won kò gbodò wí. Àgbàlagbà Òjè nikan ni wón ń ‘sé’ eégún rè bí ó bá kú. Bí a bá ti fé ‘sé’ eégún eni tí ó ti kù yìí, a ó wá pàsán1 méta, a ó wá aso fúnfún tí ó tóbi, a ó tún wá eni tí kò sé kò yè gíga eni tí a fé ‘sé’ eégún rè náà. Ìtàn so fún mi pé láyé àtìjó, tí wón bá pe òkú Òjè nígbà tí won kò bá tíì sin ín, pé ó maa ń dáhùn tí yóò sì bá àwon ènìyàn sòrò. Sùgbón eke ti dáyé, aásà ti dÁpòmù, nnkan ò rí bí í ti í rí mó nítorí pé a kò lè se é bí a ti í se é télè.
Bí àwon èròjà tí a kà sílè wònyí bá ti dé owó àwon àgbà Òjè, a ó mú okùnrin tí kò sé kò yè gíga òkú Òjè náà lo sínú igbó ìgbàlè. Àwon àgbà Òjè nìkan ni wón lè mo eni náà. Léhìn èyí, àwon Òjè yókù àti àwon ènìyàn yóò máa lu ìlù eégún ní ibi tí won ti pa pereu lébàá igbó ìgbàlè náà. Òwéwé2 ni ìlù tí a ń wí yìí. Tí wón bá ti ń lu ìlù báyìí, àgbà Òjè kan yóò máa mú òkòòkan nínú pàsán yen, yóò
1. Òpá àtòrì tí a fi irin gbígbóná se onà sí lára tí àwon tí ó máa ń tèlé eégún lo sóde fi ń na ènìyàn.
2. Aparun tàbí igi tí a fó sí wéwé, tí a sì se é pelebe pelebè.
Sì máa fin a ilè lééméta méta. Bí ó bá ti ń se béè ni yóò máa pe orúko eni tí ó ti kú náà tí a sì fé ‘sé’ eégún rè yìí. Nígbà tí ó bá ti fi pàsán keta na ilè léékéta tí ó sì tún pe orúko eni tí ó ti kú náà, eni tí ó ti wà nínú igbó ìgbàlè yóò dáùn, yóò sì máa bò pèlú aso fúnfún báláú lórí rè. Àwon ènìyàn yóò sì máa yò pé baba àwon dáhùn, pé kò tilè kú rárá.
Bí babá bá ti jáde báyìí ni àwon ènìyàn yóò máa béèrè orísìírísìí nnkan lówó rè, tí baba náà yóò sì máa dá won lóhùn. Nígbà tí ó bá ti jó dáadáa fún ìgbà díè, yóò súre fún àwon ènìyàn kí ó tó padà bá inú igbó ìgbàlè lo. Bí eégún se ń jáde lóde òní nìyí ní ìlú Ondó.
BÍ EÉGÚN ÀTI ÒGBÉRÈ EÉGÚN SE DÉ ÌLÚ ONDÓ
Gégé bí yóò ti hàn níwájú, kì í se èdè tí àwon ará Ondó ń fò lénu ni wón fi ń kógbèérè: èdè Òyó ni wón ń lò. Èyí jé ìtókasí kan láti fi hàn pé láti Òyó ni eégún ti kókó bèrè kí ó tó tàn ká gbogbo ilè Yorùbá. Ní ayé àtijó, nígbà tí ogun àti òtè pò ní ilè Yorùbá, òpòlopò àwon ènìyàn ni ogún kó láti ìlú kan dé òmíràn. Àwon mìíràn lè se àtìpó níbè fún ìgbà díè kí won ó sì padà sílé nígbà tí won bá ti ra ara. Àwon mìíràn a tilè kúkú jókòó sí ìlú náà won a sì fé Ìyàwó níbè. Béè àsà kò seé fi sílè bòrò. Àwon ènìyàn wònyí kò gbàgbé èsìn won béè ni wón sì ń gbé e