Ife
From Wikipedia
Ife
C.O. Odejobi
Ifè láti owó C.O. Odéjobí, DALL, OAU, IFÈ Nigeria.
Òpòlopò àwon asiwájú nínú ìmò ni wón ti so ìtàn ìsèdálè Ifè. Bákan náà Johnson1, Gugler, àti Flanagan2 tó fi mó Fásogbón3 so ìtàn Ifè nínú isé won. Gégé bí ìwádìí, ònà méjì ni ìtàn Ifè pín sí. Èkíní je mó ìgbàgbó nípa pé láti ìpilèsè ni Ifè ti wà. Ìtàn kejì ni èyí tí ó sun jáde láti ara Odùduwà1. Ìtàn àkókó ni ti Ifè Oòdáyé2 Ìtàn ìwásè náà so pé Olódùmarè pe àwon Òrìsà láti lo wo ilé ayé wá nígbà ti ó fé dá ayé. Ó fún won ní èèpè tí ó wà nínú ìkarahun ìgbín, adìe elésè márùn-ún, àti òga. Nígbà tí wón dé ilé ayé, wón rí i pé omi ní ó kún gbogbo rè, àwon òrìsà da eèpè tí Ooódùmarè fún won sí orí omi náà, adìe elésè márùn-ún sì tàn án. Bí adìe elésè márùn-ún se ń tan ilè yìí béè ni ilè ń fè sí i èyí náà ló bí orúko Ifè.
Ìtàn kejì ni pé láti ìlú mékà ni Lámurúdu tí ó jé baba Odùduwà ti wá sí Ifè. Ogun Mohammed tí ó jà láàrin kèfèrí àti mùsùlùmí ìgbà náà ló ká Lámúrúdu mó. Èyí ti Lámurúdu ìbá fi gbà, ó fi ìlú Mékà sílè, ó sì te Ifè dó.3 Léyìn ikú Lámurúdu ni Odùduwà gba Ipò. Ilé Òrúntó ti wà ní Ifè kí Lámurúdu tó dé. àwon ará ilé Òrúntó ni ó gba Lámurúdu àti Odùduwà ní àlejò4. Àwon ará ilé Òrúntó gbà fún Odùduwà láti jé olórì won nítorì pé alágbára ni.
Ìtàn ti akoko yìí ló so bí Olódùmarè se ran àwon orisa láti wá dá ayé. Léyìn tí àwon orisa dá ayé tan, ti wón sì ti ń gbé ibè ni Odùduwà tó wá sí Ile-Ifè láti ìlú Meka. Abénà ìmò itan kejì yìí tilè fi kún òrò rè pé Lámurúdu àti Odùduwà bá àwon kan ni Ilé-Ifè nígbà ti wón dé Ifè. Ohun tí èyí èyí ń fi yé wa nip é nibi tí ìtàn akoko parí si ni ìtàn kejì ti bere.
Àkíyèsí: A yo isé yìí láti inú àpilèko Émeè C.O. Odéjobí .