Eledumare 1
From Wikipedia
Ayorinde, Olumuyiwa Samuel
AYORINDE OLUMUYIWA SAMUEL
EKO NIPA ELEDUMARE
Àwon onímò ìjìnlè nínú èkó èsìn kírísítì á maá wí pé “Kí Májèmú ó tó dé ní Májèmú ti wà” èyí jásí pé maájèmú tí à kò ko sílè ti wà kí èyí tí à ko sílè tó dé. A lè fi èrò àwon Yorùbá nípa olódùmarè wé èrò àwon onímò ìjìnlè nínú èkó èsìn kirisiti yìí. Kí ìlàjú àti èsìn ìgbàgbó to mó òrò tí àńlò ní ló lóó yìí ní Olórun wa, àwon Yorùbá ti ńlò òrò bí olódùmarè, Elédàá, Oba Òrun, Ògá Ògo, Alábàláse, Atérerekáyé, Oba Arínúróde, Oba Olùmòrò okàn, Alèwílèse, Oba Adákédájó, Òyígíyigì, Oba Àìrí, Oba Àwàmárídì àti béè béè lo. Bí abá sì gbó tí àwon Yorùbá bá so pé ‘Orí mo ò’ tàbí ‘Olójó-òníò’, Olódùmarè ni wón ń pè ní ‘orí’ èyí tí o dúró fún elédà orí àti olójó-òní, èyí tí ó dúró fún eni tí óní ojó òní. Njé kí ni ìdí rè tí àwon Yorùbá fi ń lo orí sirísi orúko wònyí fún Olódùmarè? Bí abá ka májèmú ti láéláé lákàyé, a ó rí i pé àwon omo Heberu pàápàá kò dá a láse láti má a pé orúko Olórun won. Wón gbà wí pé Olórun tóbi ju gbogbo èdá lo, ósì jé eni tí wón gbódò má a bu olá fun àti nítorí náà wón wá orúko mìíràn tí wón ńlò dípò orúko rè gan an. Èyí tí ó se pàtàkì jùlo nínú orúko tí wón ńlò dípò olórun ní “YAAWE” Èrò okàn àwon Yorùbá ni pé Olórun tàbí Olódùmarè tó bi púpò ó sì ju enikéni lo àti nítorí èyí kò ye kí wón má a la orúko mó O lórí bí wón tí ń se sí egbé àti ogbà wón. Láti bu olá fún-un àti láti fi ìteríba wón hàn fún-un, wón ń fi isé owó rè pè é. wón ání Elédàá èyí ni eni tí ó dá òrun àti ayé; Òyígíyigì, èyí ni eni tó tóbi tóbè géé tí kò sí ohun tí àlè fì wé. Oba Àwámárìdí, èyí ni eni tí akò lè rí ìdí iséerè. Alábàláàse, èyí ni eni tó òní àbá àti àse; Bàbá; èyí ni bàbá gbogbo èdá inú ayé; Ògá ògo, èyí ni eni tí óní òrùn èyí tí ó jé ògó èdá, tàbí nígbà mìíràn a lè túmò rè sí eni tí ògo tàbí ìgbéga èdá ńbe lówó rè; Atérerekáríayé, èyí ní eni tí ó tóbi tí ó sì ni gbogbo ayé ní ìkáwó rè, Bí àba sì tún gbó nígbà míràn tí àwon àgbàlagbà ńlo àwon òrò bíi ‘Èdùmàrè’ tàbí wón ńlo àwon òrò bíi ‘Olú’olódùmarè kan náà ni wón ńtóka sí. Àwon àgbàlagbà á máa so pé
“Àsegbé omo Èdùmàre,
Mo ló dàsegbé
À se gbé omo Èdùàrè
Òhun tí àkólé yìí tóka sí ni pé ohun tí omo Èdùàrè, èyí tí ó dúró fún ohun tí Olódùmarè bá ti se àse gbé ni. Àwon Yorùbá sì maá ń pò we nígbà míràn pé “ohun tí olófin ayé bá wí náà ni Olófinòde òrun ń gbà; Olódùmarè kan náà ni wón ń pè ní Olófin. Olófin ni orúko tí a fún àwòkò tí ó kókó joba ní Ilé-Ifè. Léyìn rè ni àwon tí à ń pè ní Ooni bèrè sí í je Oba. Àwon Yorùbá gbàgbó pé òun nìkan leni tó lè sojú won, kí ó sì bá Olódùmarè sòrò. Olófin lágbára àti àse lórí àwon ènìyàn rè gege bí olódùmarè ti ní agbára àti àse lórí àwon ènìyàn rè, gégé bí Olódùmarè ti ni agbára àti àse lórí èdá ayé àti ti òrun Olódùmarè kan náà làwon Yorùbá ń pè ní Olófin - Òrun. Fún ìdí èyí Elédùmarè jé enití ó dá ayé tí ósì da òrun, ohun sin i baba ohun gbogbo