Eledumare 1

From Wikipedia

Eledumare

Ayorinde, Olumuyiwa Samuel

AYORINDE OLUMUYIWA SAMUEL

EKO NIPA ELEDUMARE

Àwon onímò ìjìnlè nínú èkó èsìn kírísítì á maá wí pé “Kí Májèmú ó tó dé ní Májèmú ti wà” èyí jásí pé maájèmú tí à kò ko sílè ti wà kí èyí tí à ko sílè tó dé. A lè fi èrò àwon Yorùbá nípa olódùmarè wé èrò àwon onímò ìjìnlè nínú èkó èsìn kirisiti yìí. Kí ìlàjú àti èsìn ìgbàgbó to mó òrò tí àńlò ní ló lóó yìí ní Olórun wa, àwon Yorùbá ti ńlò òrò bí olódùmarè, Elédàá, Oba Òrun, Ògá Ògo, Alábàláse, Atérerekáyé, Oba Arínúróde, Oba Olùmòrò okàn, Alèwílèse, Oba Adákédájó, Òyígíyigì, Oba Àìrí, Oba Àwàmárídì àti béè béè lo. Bí abá sì gbó tí àwon Yorùbá bá so pé ‘Orí mo ò’ tàbí ‘Olójó-òníò’, Olódùmarè ni wón ń pè ní ‘orí’ èyí tí o dúró fún elédà orí àti olójó-òní, èyí tí ó dúró fún eni tí óní ojó òní. Njé kí ni ìdí rè tí àwon Yorùbá fi ń lo orí sirísi orúko wònyí fún Olódùmarè? Bí abá ka májèmú ti láéláé lákàyé, a ó rí i pé àwon omo Heberu pàápàá kò dá a láse láti má a pé orúko Olórun won. Wón gbà wí pé Olórun tóbi ju gbogbo èdá lo, ósì jé eni tí wón gbódò má a bu olá fun àti nítorí náà wón wá orúko mìíràn tí wón ńlò dípò orúko rè gan an. Èyí tí ó se pàtàkì jùlo nínú orúko tí wón ńlò dípò olórun ní “YAAWE” Èrò okàn àwon Yorùbá ni pé Olórun tàbí Olódùmarè tó bi púpò ó sì ju enikéni lo àti nítorí èyí kò ye kí wón má a la orúko mó O lórí bí wón tí ń se sí egbé àti ogbà wón. Láti bu olá fún-un àti láti fi ìteríba wón hàn fún-un, wón ń fi isé owó rè pè é. wón ání Elédàá èyí ni eni tí ó dá òrun àti ayé; Òyígíyigì, èyí ni eni tó tóbi tóbè géé tí kò sí ohun tí àlè fì wé. Oba Àwámárìdí, èyí ni eni tí akò lè rí ìdí iséerè. Alábàláàse, èyí ni eni tó òní àbá àti àse; Bàbá; èyí ni bàbá gbogbo èdá inú ayé; Ògá ògo, èyí ni eni tí óní òrùn èyí tí ó jé ògó èdá, tàbí nígbà mìíràn a lè túmò rè sí eni tí ògo tàbí ìgbéga èdá ńbe lówó rè; Atérerekáríayé, èyí ní eni tí ó tóbi tí ó sì ni gbogbo ayé ní ìkáwó rè, Bí àba sì tún gbó nígbà míràn tí àwon àgbàlagbà ńlo àwon òrò bíi ‘Èdùmàrè’ tàbí wón ńlo àwon òrò bíi ‘Olú’olódùmarè kan náà ni wón ńtóka sí. Àwon àgbàlagbà á máa so pé

“Àsegbé omo Èdùmàre,

Mo ló dàsegbé

À se gbé omo Èdùàrè

Òhun tí àkólé yìí tóka sí ni pé ohun tí omo Èdùàrè, èyí tí ó dúró fún ohun tí Olódùmarè bá ti se àse gbé ni. Àwon Yorùbá sì maá ń pò we nígbà míràn pé “ohun tí olófin ayé bá wí náà ni Olófinòde òrun ń gbà; Olódùmarè kan náà ni wón ń pè ní Olófin. Olófin ni orúko tí a fún àwòkò tí ó kókó joba ní Ilé-Ifè. Léyìn rè ni àwon tí à ń pè ní Ooni bèrè sí í je Oba. Àwon Yorùbá gbàgbó pé òun nìkan leni tó lè sojú won, kí ó sì bá Olódùmarè sòrò. Olófin lágbára àti àse lórí àwon ènìyàn rè gege bí olódùmarè ti ní agbára àti àse lórí àwon ènìyàn rè, gégé bí Olódùmarè ti ni agbára àti àse lórí èdá ayé àti ti òrun Olódùmarè kan náà làwon Yorùbá ń pè ní Olófin - Òrun. Fún ìdí èyí Elédùmarè jé enití ó dá ayé tí ósì da òrun, ohun sin i baba ohun gbogbo