Orile-ede Naijiria
From Wikipedia
Orile-ede Naijiria
Gbadamosi Temitope Thomas
GBADAMOSI TEMITOPE THOMAS
ORÍLE ÈDÈ NÀÌJÍRÍÀ
Ìrìn àjò orílè èdè Nàìjíríà bérè láti bíi igba odún séìn, nígbà tí àwon òyìnbó aláwò funfun bíi potugí, Gèésì, Jamaní ati béèbéè lo, se àbèwò si orílè èdè adúláwò. Ara àwon ohun tí o gbéwon l’ókàn tí wón fii wá nii ohun àlùmónì ti ó sodo si ile yìí. Ara àwon ìgbésè kíní tí wón gbé nii láti rán àwon oni ìyìnrere èsìn kristiani wá sí orílè èdè yii. Nígbà ti àwon oníwàásù wònyíí dé, òpòlopò omo ilè yìí ti o tétí sí ìwàásù won ni ayí padà ti wón si dii onígbàgbó òdodo. Èsìn yìí gbilè l’ókàn àwon ènìyàn orílè èdè yii débi wípé won kò mo ìgbà ti àwon aláwò funfun wònyí ki òrò òwò bòó. ilé isé ti ó kókó wo orílè èdè yìí ni a mò síí Royal Niger Company. Ilé isé yìí ni óra òpòlopò ohun àlùmónì bíi kòkó, eyìn (epo), èpà, oje igi (roba) ati béèbéè lo, ti yóò si fi sowó sí ìlú òyìnbó l’óhún. Látàrí òrò òwò yìí kan-náà ni ilé isé yìí se raa ìlú èkó pa ti ósì soó dii ibùdó àwon aláwò funfun ni orílè èdè Nàìjíríà. Fún ìdí èyí, nígbàtí ó dii odún 1914, gúúsù orile èdè yii darapò mó àríwá ti àpapò rè si ńjé NÀÌJÍRÍÀ. Enití ówà léyìn orò tí óhún dún yii ni àhún pè ni Sir Fredrik Lord Lugard. Èwè, orílè èdè Nàìjírìà ti di ti àwon òyìnbó gèesì pátápátá báyìí, tí ìjoba ati ìsàkóso rè náà sì wà lówó won. Sir Fredrik Lugard dá ìjoba alábe sékélé ken sílè léyìn odún 1914 èyí tíí òpòlopò nínú àwon òùn se ìjoba wònyíí jé aláwò funfun ti díè nínú won sì jé aláwò dúdú. Lára àwon aláwò dúdú wònyíi ni ati ríí àwon oba alayé bii Aláàfin tí ìlú Òyó, oba ti ilè Banin, sultan ti ilu sókótó ati béèbéè lo. Sùgbón nígbà tí ódi odún 1922 ti Sir Hugh Clifford gba ìjoba, àbùkù débáá ìjoba ti Lugard dá sílè. Èyi l’ómú kii Hugh Clifford dáá ìjoba míràn sílè tí ósì fi ààyè gba ìdìbò alábe sékélé. Fun idi èyí àwon omo orilè èdè yii tí ó wà ni ìlú Èkó ati Calabar tí ósì ńgba tó ogún póhùn l’ódún ní ààyè àti dìbò. Ìjoba Sir Hugh Clifford jé ìjoba tí pé jùlo ni sáà àwon òyìnbó wònyíí, nígbà tí ódi odún 1946, Sír Arthur Richard gba ipò lówó Hugh Clifford. Àbùkù míràn tún báá òfin tilè yii nítorí àléébù ti ówà nínú rè. Àláébù yii nipé, òfin kò fi ààyè gba gbogbo omo orílè èdè yii tí ó tóó dìbò lati kópa. Sir Richard látàrí èyí wá dáá òfín míràn sílè tí ókó gbogbo gúúsù ati àrí’wa orílè èdè yii papò l’ábé ìjoba kannáà, èyí tí òfin ti télè kò fii ààyè gbà. Ní odún 1951, Sir John Macpherson tún gba ìjoba l’ówó Sir Richard ti àléébù míràn tún bá ìjoba tirè náà. Sir Macpherson náà dáá ìjoba kan tí ófé fii ara pé Àpapò (Fédírà) sílè. Sùgbón ìjoba rè yìí kò fi esè múlè rárá ti asojú si àwon ìletò tii ilè Gèésì fii pe ìpàdé àpapò látáríi èdè àíyédè tí ó bé sílè l’áàrín àwon ènìyàn gúúsù ati ti àríwá oríle èdè yii. Asojú si ìletò Gèésì yii ni orúko rè ńjé Oliver Lyttleton, ohún l’ó yanjú dàrú dàpò yii nígbà ti o dáá ìjoba. Àpapò sile ní odún 1956. Léyìn odún mérin tí ìjoba ati òfin Oliver Lyttleton fesè múlè, ìdìbò gbogbogbò wáyé ni odún 1959, oríle èdè Nàìjíríà gba òmìnira ni odún 1960. Àmó tí abá wòó njé òmìnira wà ní orílè èdè Nàìjíríà l’òní bí?