Agemo
From Wikipedia
C.O. Onanuga
C.O. Onanuga (1981), ‘Agemo’ láti inú ‘Odún Òrìsà Agemo ní Agbègbè Ìjèbú-Òde.’, Àpilèko fún Oyè Bíeè , DALL, OAU, Ifè, Nigeria, ojú-ìwé 17-20.
Agemo
ÌPÒ ÒRÌSÀ AGEMO LÁÁÀRÍN ÀWON ÌJÈBÚ.
Agemo ni àwon Ìjèbú gbà sí àgbà fún gbogbo òrìsà yòówù ní ilè Ìjèbú. Enì kan, tàbí àgbáríjo pò àwon díè lè se odún Ògún tàbí tí Ifá fúnra won. Sùgbón èyí kò rí béè fún odún Agemo. Gbogbo omo ilè Ìjèbú nilé lóko ni odún Agemo kàn.
Ní àtijó, ìpò Olódùmarè ni a gbó pé àwon Ìjèbú fi Agémò sí. Ìtàn tilè fi hàn pé àwon òrìsà yòókù fi ìgbà kan gbógun ti Agemo nítorí wón ń jowú ipò rè gégé bi olórí. Sùgbón bí wón ti tiraka títí, won kò lè ségun Agemo. A lè fi ìtàn yìí wé bí àwon òrìsà ti gbógun ti Olódùmarè ní ojó kìíní. Bí Agemo ti se pàtàkì tó nílè Ìjèbú hàn nínú oríkì Ìjèbú pé –
“Ìjèbú, omo Alárè
Omo Agemo òfú yòwò yòwò
Ewé dúdu oróro…”
[B] BÍ ODÚN AGEMO SE WÁYÈ
A kò tíì lè so pàtàkì bí odún Agemo se wáyé. Ìdí nip é orísìírísìí ìtàn ni ó wa lórí ìsedá odún Ágemo. Àwon ìtàn wònyí máa ń yàtò síra won gédégédé tó béè tí yóò fi sòro láti fi owó mú òkan.
Ìtàn kan so fún ni pé láti Ilé-Ifè ni òkòòkan àwon olójà Agemo ti dide. Kálukú won tè dó sí ibi tí wón wà dòní. Ní odún kan ni Awùjalè se àpèje fún won ní Ìjèbú-Òde, tí àwon náà sì sàdúrà fún oba. Gbogbo àdúrà tí wón se fún oba lódún náà ni ó se. Ìdí sì nìyí tí Awùjalè fi ń pè wón jo lódoodún láti wá máa se àdúrà fún òun. Ìtàn kan bí odún Agemo se bèrè nìyí.
Ìtàn mìíràn so pé látí Adó (Ekìtì) ni Agemo ti wá, tí ó sì dó sí agbègbè tí a mò sí Ìjèbú-Imusin fún ìgbà díè. Kò yé nib í ó se jé bí Agemo se dé Ìjèbú Òde. Sùgbón olójà Agemo kan (Olójà Nópà) wà ní Òdo-Nópà, ní Ìjèbú-Imúsin.
Ìtàn mìíràn fi yé nip é tègbón-tàbúrò ni Agemo àti ‘Awùjálé’. Awùjalè jé eni kan tí ó máa ń gbàdúrà ìdákéjéé sí Elédà rè láràárò àti lálaalé. Sùgbón agogo ni Agemo máa ń lù láràárò àti lálaalé ní tirè. Èyí máa ń dí Awùjalè lówó nígbà tí ó bá ń gbàdúrà rè. Nitorí èyí, Agemo kó lo sí Odò-Aye ní èbá Imùkù, ní tòsí Ìjèbú-Òde. Láti ibè ni òun àti àwon àtèlée rè tí ó fón káàkiri ti máa wá ń bá Awùjalè seré lódoodún ní Ijèbú-óde. Títí di òní sì ni Olójà Bájèlú Olúmùkù ti Imùkù máa ń lu agogo irú èyí tí Agemo máa ń lù ní ìjósí.
Alàgba Ògúnbawo, Omo Olúmosàn tún ní ìtàn tí ó yàtò láti so nípa bí Agemo se dé ilè Ìjèbú. Àlàgbà Ògúnbawo gbà pé láti ìdílé òkan nínú àwon ayaba Sólómónì ni a tí mú Agemo wo ilú Jerúsálémù, láti Ìjíptì (Egypt). Gbájúmò obìnrin kan, ayaba sóbà ni ó sì mú òrìsà Agemo wá láti Jerúsálémù sí ilè Ìjèbú. Alàgbà Ògúnbawo tilè tóka sí àwon òrò kan tí ó gbà pé kì í se èdè Ìjèbú, tí àwon alágemo yá láti inú èdè Ijíptì àti tí Jerúsálémù. Fún àpeere, ó ní “Eèèkeèè” tí àwon Alágemo ń lohùn já sí “En que” tí ó túmò sí “e bilà”.
Síbè, àwon mìíràn ní òrìsà tí Obáńta mú wá láti Ilé-Ifè ni Agemo. Sùgbón a kò rí èrí tó láti gbé àwon ìtàn yìí kí a fi lè mo okodoro-òrò. Lójú olóye Tàmì (olórí Agemo?), a kò lè mo bí Agemo se wáyé, Òun kò gbó o rí kì a máa so ìtàn ìsèdá Agemo, nítorí bí ìgbà tí a ń se ìwadìí ìtàn ìsèdá Olódùmarè ni yóò rí tí a bá ń wádìí ìsèdá Àgemo. Ólóyè Tàmi gbà pé “àwámárídìí ní ìsédá Agemo”.
Lójúu tèmi, ó dájú pé òrìsà Agemo tí wà ti pé ní ilè Ìjèbú. Se bí àwon kan ni ó pilè wà nilè Ìjèbú kí ó tó di pé àwon kan wá bá won láti ìbòmíràn. Bí ó ti seé kí àwon àkòhùnrìnwá yìí mú èsìn àjèjì wo ilè Ìjèbú, béè náà ni ó seé se kí wón bá èsìn ibílè àwon onílè gaan. Ohun tí ó mù mi so èyí nip é, a kò lè fi gbogbo ara gba gbogbo àwon ìtàn òkè tí ó ń so pé ibì kan ni a ti mú òrìsà Agemo wá. Nípa pé Ilé-Ifè ni Agemo ti wá, tàbí pé Obańta ni ó mú Agemo wo Ìjèbú, ó sòro láti gbàgbó. Ìdí ni pé, ó ti di àsà ní ilè Ìjèbú láti máa só àwon ohun ìsènbáyé mó òrísun’ méjèèjì yìí. Kálukù tí ó bá fé kí àwon ènìyàn tétí sí ìtàn òun ni ó sì máa ń topasè àwon orísun wònyí nítorí wón gbà á sí nnkan iyì tàbí ògo pé nnkan tiwon náà tan mó Obáńta, tàbí Ilé-Ifè.
Òjògbón Oyin Ògunbà (1967) lè so pé –
“… Tí a bá ní kí a so pàtó ohun tí a rè
nípa ìsèdálè Agemo a ó so pé Agemo tí wà
láíláí ní ilè Ìjèbú kí Obánta tó dé.
Ó tilè seé se kí ó tó egbàá odún kí obańta
tó dé, ki ó tilè jé pé ń se ni … Obańta … so ó di tirè…” Bóyá ìdí nìyí tí a fi ń ki Agemo pé –
“Òrìsà èé róbaá mù,
róba mí bo ó”
(“Òrìsà tí oba kò mò, tí oba ń bo)
Ó lé jé pé nígba tí awon àtòhúnrinwá yìí (Obańta?) dé ni wón bèrè sí se àyípade sí èto odún náà, tí kálukú fi wá ń so orísìírísìí ìtàn.
Ní kúkúrú, èròo tèmi nip é ó seé se kí orísà Agemo jé òrìsà àpilèni tí àwon tí ó ti wà nílè Ìjèbú láti ìgbà láíláí-orúko yòówù kí àwon ènìyàn náà máa pe ara won. Lóná keji, kì í se pé kò seé se kí òrìsà Agemo jé àtèkèèrèwá súgbón ó dájú pé ójó òrìsà náà ti pé púpo nílè Ìjèbú. Bí ó bá se Obańta ló mú u wá, èyí tit ó egbèta odún séhìn bí ó bá sì se ayaba Sébà (Queen of Sheba) ni ó mú u wá láti Jerúsálémù lódò Oba Sólómóní, ó tí lé ni egbèwá odún.
[D] OHUN TÍ IFÁ SO NÍPA AGEMO
Níwòn bí Ifá ti jé ‘Akéréfinusogbón …. ….òpìtàn ilè - Ifè.
A-kó-ní-lóràn-bí-ìyékan eni…”, ó ye kí a lè mo òkun tí ó níí so fún wa nípa òrìsà Agemo.
Ese Ifá kan nínú àmúlù odù ÒTÚÚRÚPONGBÈ se àlàyé bí ó se jé tí Agemo kì í se òrìsà tí wón fi gbogbo ara mò níbòmíràn àfi ilè Ìjèbú.
“A ń pon mógbè
Mógbè ń pòngbá
A dífe fÓlomo-takìtì gbegbàá…”
Olómo-a-tàkìtì-gbegbàá ni orúko mìíràn tí a ń pe Agemo. (Lórí isé tí enì kan bá ń sé, tabí ìwà tí ó bá ń hù ni Ifá máa fi ń pe olúwarè). Ifè Oòdáyé ni Agemo wà télè; idí tí a sì fi ń pèé ní atàkìtí-gbegbàá nip é Olomo féràn láti máa ta òkìtì púpò. A máa ta òkìtì débi i pé ó máań fo àwon nnkan gíga gíga.