Ekun Oro

From Wikipedia

Eku Oro

A.F. Bamidele

ÌTÀN ORÍRUN EKÙN ÒRO LÁTI OWÓ A. F. Bámídélé, UOA, Adó-Èkìtì, Nigeria.

Ekùn Òrò jé òkan lára àwon ekùn ilè Ìgbómìnà ní ìpínlè Kwara. Lára àwon ekùn Ìgbómìnà tó kù ni ekùn Àpà, ekùn Èjù, ekùn Ìrèsé, èkun Òró àti ekùn Àrán. Àwon ìlú abé ekùn Àpà ni Agbondà, Omido, Adigun, Oko-Àwòrò àti Egúdu. E`kun Àrán ni a ti rí ìlú bíì Omù-Àrán, Àrándùn, Àrá-Òrìn, àti Roré. Ní ekùn Èjù ni a ti rí Igbóńlá àti Sanmora. Ekùn Ìrèsé ni a tí ri Ìgbànà, Àdáńlá, Òfàrèsé àti Òbín. Ekùnmésàn-án Òró ni a ti rí àwon ìlú bíì Òtún-Òró, Òkèrímì-Òró, Òkè-Olà-Òró, Ìlúdùn-Òró, Agbé-Ola Òró, Irébòdé-Òró, Sìè-Òró, Ìjomu-Òró àti Ìdó-Òró.

Ekù Òrò (ekùn náà ni a ń pè ní ekù ní àdúgbò yìí) wà lára àwon omo bíbí Odùduwà tí wón wá láti Ilé-Ifè. Dáda (1965) so o di mímò pé ojó ti pé ti baba ńlá àwon ènìyàn ekùn yìí ti wá tèdó sí orí ilè tí à ń pè ní Òrò lónìí. Ìtàn yìí tè síwájú pé òkan lára àwon omo odùduwà ló wá tè é dò. Olóyè James, eni àádórin odún, so pé abé ìsàkóso Odùduwà ni gbogbo ilè tí a mò sí Òrò lónìí wà ní ìgbà náà. Nígbà tí àwon ènìyàn wònyìí dé, a gbó pé Òkè-Owá ni wón kókó tèdó sí tí wón sì kólé won sí. Olóyè James tèsíwájú pé àkókò yìí ni Ogun Agánnigàn gbilè bí òwàrà Òjò. Ogun yìí ni ó fón òpòlopò àwon ènìyàn wònyìí kiri tí won tún lo tèdó sí àwon ìlú mìíràn bíì Òrà, Òkè-Ode, Bàbáńlá àti Ògòòrò àwon ìlú mìíràn ni ìjoba Ìbílè Ìfélódùn. Ní báyìí, òpò ìlú wònyìí kìí se ara ekùn Òrò, (nítorí wón ti jìnnà sí ekùn Òrò béè sì ni èyà èka-èdè Ìgbómìnà won yàtò dé àáyè ibi kan sí èka-èdè Ìgbómìnà Òrò) wón sì máa ń rí ara won bí omo baba kan náà.

Alàgbà Arówólò làti Òmùgo, eni omo odùn métàdínlógórin) jérìí sì ìtàn tí ó so pé ó tó ogún séntúrì tí àwon ènìyàn Òrò tí sòkalè láti orí òkè Owá sí ibi pètélè ó tún tè síwájú pé nígbà tí won dé ibi pètélè yìí ni wón bèrè si kó àgó káàkiri fún àábò ara won. Léyìn tí won sòkalè ní orí òkè yìí ni wón wá so ara won di Ìdòlú, èyí túmò sí àwon ènìyàn tí wón ti wà papò ti pé tí wón sì ń gbé ibìkan náà. Ìtàn fi yé wa pé lára orí òkè tí àwon ènìyàn wònyìí ti sòkalè wá ni Òkèmure, Òkèlúwúro, Ayétòrò, Òkèdábà wá-ni-Òkèmure, Òkèlúwúro, Ayétòrò, Òkèdábà àti Òkè-Ayìn. Ní báyìí a ti rí tó ìlú méèédógún ní abé èkùn Òrò. Ìdí sì nìyí tí wón fi ń pe ekùn yìí ni akù méèdógún Òrò. Ekùn Òrò ní báyìí bèrè láti Òmùgo, àwon Ìlú tó kù ni Òkè-dába, Ajégúnlè, Ìràbòn, Àgó (Òrò-Àgó) Àhún, Òganyìn, Àgó-Olómo, Oyátèdó, Òkè-Àyìn, Òkè-Owá, Ìlàfè, Òkèmure, Ayétòrò àti Aráròmí.

Ní ìbèrè pèpè, isé àgbè àti ode ni àwon okùnrin wón ń se tí àwon obinrin sì máa ń re aró tí wón sì ń se òrí. Èsìn Ìbílè gbilè púpò ní ekùn yìí kí àwon elésìn àtòhúnrìnwá tó dé.

Àkíyèsí: A yo isé yìí láti inú àpìlèko Émeè A.F. Bámilélé