Oku Pipe

From Wikipedia

E.T. Olowookere

Oku Pipe

E.T. Olówóòkéré (1975), ‘Okú Pípè’, Apileko fun Oye Biee, DALL, OAU, Ifè, Nigeria.

Òkú pípè ni orin arò tí a máa ń ko nígbà tí ènìyàn wa bí ìyá tàbí bàbá bá kú. Orin arò yìí kún fún òpòlopò òrò láti kédùn, láti so ìtàn ìgbési ayé eni tí ó kú, láti kéde fún gbogbo aládùúgbò pé “eja ńlà lo lómi.”síwájú si òkú pípè fún wa ní ànfàní láti rántí àwon eni wa tí ó ti kú tí won ti lo sí “ilé ńlá”. Níwon tí ó jé pé oríki orílè kún fún ìtàn ìràndíran, ó jé àsà fún àwon tí won bá ń pe òkú láti mú oríkì orílè lò gégé bí irin isé pàtàkì fún orin arò tí won fé ko.

Ìdí tí àwon Yorùbá fi ń pe òkú ni láti dárò1 eni won tí ó lo sílè ayárayé. Nígbà tí àwa ènìyàn ti jo ń je, tí a ti jo ń mu sùgbón tí ó wá di eni tí a kò lè rí mó dandan ni kí dárò láti fi ìfé hàn sí eni tí ó kú náà.

Pípè tí àwon obìnrin ń pe òkú ni láti wá ònà láti gba owó lówó omolóòkú. Ìgbà tí won bá ti ń pe ìyá tàbí bàbá, won a máa fihàn pé omolóòkú náà ni yíò dípò baba rè tí yíò sì dí àyè pàtàkì tí bàbá tàbí ìyáa rè ti fi sílè. Ìgbà tí won bá ti ń pe ìyá tàbí bàbá tí ó kú orí àwon omolóòkú máa ń wú. Won a sì máa fún àwon tí

1. Babaláwo tí mo se ìwádìí lódò rè Ògbéni Jímò ténúmó èyi púpò.

ń pe òkú náà lówó. Ònà láti jeun ni àwon obìnrin ń wá tí won fi ń pe òkú nítorí èérí ara wa ni àwon obìnrin.

Ìdí míràn tí a fi ń pe òkú nip é gégé bí ìpìlè tí kálukú tin í àjobi1 rè lórun, won a máa ki òkú kí olúwarè lè mo òdò àjobí rè kí ó si darapò mó won. Kí Olódùmare gbà á sí aféfé rere. Ìgbàgbó Yorùbá ní pé bí won bá ti ń ki òkú náà yíò mo ònà tí òun yíò tè sí. Mòlébí kálukú ni yíò tò lo. Yorùbá gbàgbó pé bí won bá ti ń ki olúwarè kò ní sìnà. Ìgbà tí won bá ti ń ki olúwarè ni Olódùmarè yíò mo ibi tí eni náà ti sè wá bí omi. Yorùbá gbàgbó pé ìgbà tí a bá kúrò nínú ayé yìí inú àjobí wa ni a ń lo lórun nítorí àtò ni àtò ó yà. Fún ìdí èyí òkú tí a ń pè ni láti ran eni tí ó ń lo sí òrun lówó kí ó lè mo ibi tí òun yíò yà sí.

Òkú pípè tún jé ayeye tí ó máa ń mú òkú dùn. Ìdí ní pé bí ènìyàn bá kú tí gbogbo àdúgbò dáké róró, òfò ni irú èyí. Sùgbón bí won bá ń pe òkú náà yálà omolóìkú ni tàbí àwon obìnrin ilé tàbí àwon alágbe ayeye òkú náà yíò fi dùn ni. Nínú òrò orin tí àwon tí won ń pe òkú yìí ń ko ni àwon tí won bá wá yíò fi máa dárayé.

Sugbón bí gbobgo nnkan bá dáké róró àwon ènìyàn ko ní pé tí won yíò fi fé máa lo sí ilé won nígbà tí ó bá sú won.

1. Babalawo Tifáse so nipa àjobí wa tí ó wà lórun.

Òkú pípè kún fún òrò ìwúrí ti ó lè mú kí ènìyàn tétí sílè láti kó òpòlopò èkó. Àwon òrò ìwúrí wònyí ni a máa ń gbó nígbà tí won bá ń so pé “ó di àrìnnako, ó dojú àlá, ó doko aláwo”. Irú awon gbólóhùn báwònyìí a máa mú ènìyàn lókàn nítorí a kì í dédé máa gbó irú òrò béè láì jé pé ènìyàn kú.

Òkú pípè pín sí orísìírísìí ònà. Àwon omolóòkú àti ebí òkú máa ń pe òkú bí won bá níyè nínú dáadáa. Àwon obìnrin ilé àti àwon alágbe tí won ń fi òkú pípè se isé se máa ń pe òkú.

Ní pàtàkì àwon òbìnrin ni wón máa ń pe òkú nítorí pé won a máa ní àánú lójú ju okùnrin. Àwon obìnrin a tete máa sokún tí won yíò sì máa so òrò jáde lénu. Bí ìyá kan tàbí bàbá kan bá kú tí olúwarè sì ní omo sáyé àwon omo rèyíò máa pe òbí náà láti dárò òbí won tí ó fi wón sílè. Bí eni tí ó kú náà kò bá bímo rárá tàbí kò bí omobìnrin, àwon ebí eni náà lóbìnrin yíò máa pè é. 1Ìwà rere tún se pàtàkì nítori ojó àtisùn eni. Bí ènìyàn kò tilè bímo sùgbon tí ìwà rè dára nígbà tí ó wà láyé àwon tí ó ti se lóore yíò “2san ojó” bí olúware bá kú

1. Ìdòwú, B. Olódùmarè God in Yorùba Belief p.189 Ìdòwú so nípa “Èhìn ìwà” “After-Life”. Èyí se pàtàkì nínú ìgbésí ayé èdá.

2. San ojó = sanjó : Kí ènìyàn san oore tí enìkan ti se sáájú padà. Ènìyàn lè sanjó fún ènìyàn nígbà tí ó wà láyé tàbí nígbà tí ó kú tán