Oriki Orile
From Wikipedia
Oriki Orile
Adeboye Babalola
Awon Oriki Orile Metadinlogbon
Adeboye Babalola (2000), Àwon Oríkì Orílè Métàdínlógbòn. Ìkejà, Nigeria: Longman. ISBN 978 026 029 3, ojú-ìwé 314. Òro Àkóso
Àwon Yorùbá bò, wón ní: “T’eni ni t’eni, àkísà ni ti ilé iná.” Wón sì tún ní: “Onígbá ní í pe igbá rè ní àákàràgbá kí á tóó bá a fi kólè.” Àwa mò dájú pé èdè Yorùbá wa yìí kún, ó dùn, ó se pàtàkì, ó lárinrin, ó sì jojú gidigidi. Nítorí náà okàn wa máa ń gbogbé ni, nígbà tí a bá gbó òrò àwon tí ń bu èté lu èdè yorùbá. Àníyàn wa sì nip é kí irú àwon ènìyàn béè ó má lè jàre èdè Yorùbá náà. Saájú sáà tí a wà yìí, a lè wí nípa àwon tí ń yo sùtì sí èdè Yorùbá, pé ejó won kó, ejó dídáké tí àwon agbòròdùn èdè Yorùbá dáké ni. Òken nínú àwon èébú tí àwon t’áa wí máa ń bú èdè Yorùbá ni pé kò ní lítírésò kankan dà bí àrà. N’íwòn ìgbà tí èdè Gèésì t’ó jé èdè àjùmòlò jákèjádò ilè Nàìjíríà sì ti bèrè sí i gba àyà l’ówó èdè abínibí tiwa, ara ohun t’ó ń selè nip é tí àwon òmòwé Nàìjíríà bá ti ménuba lítírésò, èrò won kì í so sí lítírésò mìíràn àfi lítírésò oní Gèésì. Won kì í ronú já lítírésò ti èdè mìíràn rárá, àfi ti èdè Gèésì nìkan soso. Ó jo pé won kò tilè mò pé lítírésò Faransé wà, lítírésò Jámánì wà, lítírésò Rósíà wà, lítírésò Yorùbá wà, lítírésò Haúsá wà, lítírésò Ìgbò wà, lítírésò Àméríkà wà, àti béè béè lo.
Kí ní í jé lítírésò? Káàkiri àgbáyé ó hàn gbangba pé ohun tí ń jé lítírésò ni àkójopò ìjìnlè òrò ní èdè kan tàbí òmíràn, ìjìnlè òrò t’ó já sí ewì, àròfò, ìtàn-àròso, àló àpamò, ìyànjú, ìyànjú, ìròyìn, tàbí eré-onítàn, eré akónilógbón l’órí ìtàgé. K’ó sì tóó di òrò kíko sílè àti títè jáde. Nínú ìwé, lítírésò lè wà nínú opolo-orí àwon òmòràn. Àlàyé tí a níláti se rèé nípa lítírésò Yorùbá. Nínú opolo-orí àwon òmòràn láti ìran dé ìran ni òrò ìjìnlè Yorùbá wà títí di òníolónìí. Ayé wáá di ayé òyìnbó, ó di ayé ìwé kíko àti ìwé kíkà. Nítorí náà lítírésò Yorùbá gbódò di kíko sínú ìwé àti kíkà nínú ìwé.
Inú mi dùn pé mo ti tètè rí àwon omo EGBÉ ÌJÌNLÈ YORÙBÁ ti ÈKA ÌBÀDÀN àti àwon ti ÈKA ÉKÓ tí wón yòòda ara won fún aáyan kíko ìwé lítírésò Yorùbá lórísirísi. Bákan náà ni inú mi dùn pèlú pé mo tètè rí Ògbéni Leslie Murby, Alákòso àgbà ni ibi-isé WILLIAM COLLINS AND SONS LIMITED, GLASGOW, tí ó ní ìtara nípa àgbéjáde lítírésò Yorùbá, tí ó sì fowósòyà pé, l’órí àdéhùn, ibi-isé òun yóó te gbogbo àwon ìwé lítírésò Yorùbá tí a bá pilè ko fún ètó tuntun yìí. Láìsàníàní, ó ye kí n dárúko àwon àwon mélòó kan nínú àwon ònkòwé tí yóó ko ìwé fún ètò náà: Òjògbón Adéagbo Akinjógbìn, Ògbéni Olúsojí Ògúnbòwálè, Òjògbón Wándé Abímbólá, Òjògbón Afolábí Olábímtán, Ògbéni Olánípèkun Èsan, Ògbéni Oládiípò Yémiítàn, Ògbéni Adébáyò Fàlétí, Olálékan Oníbìíyò.
Ó dára ò. Wón ní: “Enu l’à á mo dídùn obè.” Ó ku kí èyin ònkàwé wa ó ra àwon ìwé wa náà, kí e kà wón ní àkàyé, kí e sì gbádùn won. Ní ìkadìí òrò ìsáájú yìí, mo féé ko orin kan ní ohùn orin ilè wa:
Bí bábá bímo bí kò bímo.
Èrò yà!
Èrò yà wáá wò ó!
Èrò yà!
Bí Yorùbá ní lítírésò bí kò ní lítírésò, èyin ará e ya ilé ìtàwé, kí e sì wo àwon ìwé wa tuntun wònyí. Àrímáleèlo ni wón, à-kò-pinnu-láti-rà; à-rí-yowó-lápò-fi-fún-òntàwé.
Ire o!