Awon Onkowe

From Wikipedia

O.O. Adebajo

Awon Onkowe

Adebajo

O.O. Adébàjò (1991) ‘Agbeyewo Ise Àwon Asiwaju Onkowe Yorùbá Lati Odun 1848 si Odun 1938.’, Àpilèko fún Oyè Émeè, DALL, OAU, Ifè, Nigeria.

ÀSAMÒ

Ohun tí ó se kókó tí ó sì je wá lógún nínú ìwádìí yìí ni síse àgbéyèwó isé àwon asíwájú ònkòwé Yorùbá láti odún 1848 sí odún 1938. Nínú àyèwò isé wònyí irú-wá-ògìrì-wá ni a ó fi isé náà se. Kì í se wí pé dandan ìwé tó dá lé lítírésò nìkan la fé yèwò. Sùgbón nítorí ìmòwa tí kò kún tó lórí ìmò lìngúísíìkì àti èdá-èdè, a kò ní se àgbéyèwò àwon ìwé tó dá lé èdá èdè àti àwon ìwé atúmò gbogbo. Kókó méjì tó gbòòrò lá fi gbé ìwádìí yìí kalè Àwon ni:

(a) Síse àgbéyèwò isé àwon ònkòwé ìsáájú láti ìbèrè pèpè tí í se odún 1848 sí odún 1938.

(b) Wíwo ààtò, àgbékalè àti orísirísi ònà-èdè tó fara hàn nínú àwon ìwé tó wà lójà ní sáà tí a mú enu bà.

Láti lè se àseyorí isé yìí a lo ànfàní wònyí:

(a) Àwon ilé-ìkówèé-ìsúra-pamó-sí (National Archives) tó wà ní ìbàdàn àti Èkó.

(b) Èka ilé-ìkàwé African ní Yunifásítì Ìbàdàn.

(d) Èka ilé-ìkàwé ti Gandhi ní Yunifásítì Èkó.

(e) Ilé-ìkàwé ìjoba ìpinlè Oyó-ìbàdàn, ìpínlè Ògùn-Abéòkúta, ìpín Ondo- Àkúrè.

(e) Ilé-ìkàwé ìjoba ìbílè Abéòkúta tó wà ní Aké àti ti ìjoba ìbílè ìjèbú-Òde tó wà ní ìtóòrò.

(f) Ilé-ìkàwé àdáni àwon wònyí: ti ìjoba Àgùdà (G.C Peter and Paul) Ìbàdàn, ti Bísóòbù Seith Irúnsèwé Kalè- Mobalùfòn, ìjèbù-Òde, ti alàgbà Adégbóyèga, óbándé, Èkó, ti olóògbé Alùfáà D. Olarimiwá Epégà, Èkó.

(g) ìfòròwánilénuwò pèlú àwon wònyí tí wón jé àgbà nídìí èkó Yorùbá: Bísóòbù T. t. Solaru, Bódìjà, Ìbàdàn, olóògbé Olóyè J.O. Ajíbólá, Fòkò, Ìbàdàn, olóògbé O.O. Epégà, Èkó, alàgbà Adégbóyèga, óbándé, Èkó alàgbà J.O Odùmósù, Ìjèbú-Òde, alàgbà S.A. Òkúbàjò ti ìsònyìn ìjèbù àti olóyè E.B. Órunké-Amònà oba Aláké, Abéòkúta.

Ni orí kinni isé yìí ni a ti se àsàrò lórí akitiyan àwon asáájú ònkòwé Yorùbá sáà tí a ń yèwò, a sì gbìyànjú láti so ìtàn ìgbésí ayé won àti ohun tó ta wón nídìí kíko ìwé Yorùbá. Ní orí kejì ìwádìí yìí ni a ti se àlàyé ààtò àti àgbékalè àwon ìwé tí a yèwò. A pín èyí sí ònà méjì: (a) àwon ìwé tó je mó lítírésò àti (b) àwon ìwá aláìjemó lítírésò Àkóónú àwon ìwé wònyí la yèwo ní orí kéta àti ekérin. Fínnífínní la wo èyí lábé ìsòrí ajemó lítírésò fún orí keta, àìjemó lítírésò fún orí kérin. Ìsowó lo èdè àwon ònkòwé ìsáájú la yèwò ní orí kárùn-ún. Àgbálogbábò la fi kádìí ìwádìí yìí nílè. Níhìn-ín ló ti hàn sí wa pé isé ńlá ni kíkó àwon ìwé sáà tí a ń yèwò jo. Yàtò sí èyí, a rí i pé àwon ìwé tí kò dá lé lítírésò náà se pàtàkì nítorí pé láti inú àyèwò won a rí òpò nnkan nípa ìgbé-ayé àwa Yorùbá nípa orò-ajé, ètò ìsèlù àti ètò amáyéderùn.