Orinlaase

From Wikipedia

Orinlaase

J.B. Agbaje

Ilawe-Ekiti

J.B. Agbájé (1980), ‘Òrínlááse’, DALL, OAU, Ifè Nigeria. ÒRÍNLÁÁSE GÉGÉ BÍ ÒRÌSÀ ÌTÀN ÌGBÀ ÌWÁSÈ NÍPA BÍ ÒRÌSÀ YÌÍ SE DÉ ÌLÚ ÌLAWÈ-ÈKÌTÌ

Òrínlááse jé Òrìsà tí ó máa ń sòrò bí ènìyàn àti pé gbogbo òrò rè ni ó máa ń se. Pèlú àse ni Òrìsà yìí máa ń sòrò nítorí pé bí ó bá so fún ènìyàn pé kí ó má se jà tàbí se ohunkóhun sùgbón tí olúwarè bá sì fi gbígbó sàìgbó, dájúdájú eni náà yóò rí nnkan tí ojú pálábá rí lójó tí owó pálábá ségi.

Ní ìsèdálè ayé “OLÜAAYÉ” ni orúko òrìsà yìí sùgbón ó tún máa ń jé àwon orúko mìíràn bíi: Òrínlááse, Àdìmúlà, Àjàká àti Olúorókè. Olúaayé yìí gaan ni orúko rè gidi àti pé ìnagije ni orúko mérèèrin ìyókù gégé bí àwòrò ròsìsà yìí ti se àlàyé fún mi ní àkókò ìwádìí yìí. Ìse àwon Yorùbá ni láti máa fi ohun ìní tàbí agbára èdá hàn nípa orúko àníjé tàbí oríkì tí a bá fún un. Ó dàbí eni pé Òrìsà yìí féràn ìnagije ju orúko gidi lo, mo sì rò pé ìdí nìyí tí ó fi jé pé orúko ìnagije ni a sábà máa ń bá pàdé nínú ewì àti orin rè. Inú orúko ìnagije ni a ti ń mo akitiyan, agbára àti isé tí ó je mó òrìsà kòòkan. Mo sì rò pé ń kò ní jayò pa tí n bá so pé bóyá ìdí nìyí tí Òrìsà yìí fi féràn orúko ìnagije rè ju orúko gidi lo.

Gbogbo àwon orúko ìnagije wònyí ni ó sì ní ìtumò ti won.

Fún àpere:

ÀDÌMÚLÀ: èyí jásí pé eni tó bá fi okàn tè é yóò rí ìgbàlà. ÀJÀKÁ:- èyí tóka sí pé gbogbo ibi ni ojú rè tó lati yo àwon omo rè nínú ewu níbikíbi àti ní ìgbàkigbà ní orílè - èdè àgbáyé. OLÚORÓKÈ:- èyí fi hàn pé orí òkè ni ibùgbé òrìsà yìí wà. “onílé – orí-òkè”. Ìdí nìyí tí a fi ń kì íbáyìí pé:

“Ako umolè ko dúró sí ìsààsáá òkúta”.

ÒRÍNLÁÁSE:- èyí túmò sí pé òrò rè tí ó máa ń se. “òrò -re - ni – ó-se”; pèlú gbogbo òrò rè tí ó máa ń se ni won fi ń kì íbáyìí pé:

“Ó wí béè se béè,

Òrín Àwè kèé fò síse”.

Ìtàn àtenudénu so fún wa pé Òrínlááse jé òken pàtàkì nínú àwon òkànlénírúnwó irúnmolè tí ó sòkalè láti òde ìsálórun wá sí òde ìsálayé. Ìtàn yìí kan náà fi yé wa pé Ifè - Oòdáyé ni gbobgo àwon òrìsà kó dúró sí. Sùgbón nígbà tí ó yá, kálukú won bèrè síí lo sí ibi tí ó wù ú láti fi se ibùdé. Àwòrò òrìsà yìí fi yé mi pé, ìtàn ìgbà ìwásè so fún wa pé, bí Olúmo 1* lo sí òde Ìsánlú béè gégé ni Òrìsà Òrínlááse gba ònà ìlú Ìlawè wá dúró sí. Ìtàn yìí fi yé ni síwájú síi pé Òrìsà Òrínlááse dúró simi ní àwon ìlú bíi Èfòn Aláayè – Èkìtì,

1* Olúmo jé Òrìsà òde Ègbá

2* Olóóta jé òrìsà kan ní ìlú Adó – Èkìtì

3* Òrògìdìgbò jé òrìsà kan ní òde Ìsánlú.

Ìgèdè – Èkìtì àti Ìgbàrà- Odò – Èkìtì kí ó tó wá dúró pa sí Ìlawè - Èkìtì àti pé ìdí nìyí tí ó fi jé pé ìlú Ìlawè nìkan ni ó ti ń sòrò bí ènìyàn. Mo sì rò pé eléyìí ló se okùnfà tí àwon èniyàn fi máa ń wá sí òdò Òrìsà yìí ni ìlú Ìlawè - Èkìtì láti orígun mérèèrin orílè - èdè wa láti wá se àyèwò sí ìsòro won. Àwon mìíràn máa ń ránsé láti ìlú àwon aláwò funfun pé kí àwon ènìyàn won lo bá won se àyèwò nípa bí won yóò se yege nínú èkó tàbí àseyorí nínú isé tí won bá dówó lé.

Ká má dé èènà penu, Òrìsà yìí sì wà ní Ìlawè dib í a ti ń sòrò yìí. Fún àpere, orin tí àwon olùsìn àti àwòrò rè máa ń ko nígbà odún rè láti fi se àpónlé fún un fi hàn pé Ilé - Ifè ni ó ti wá. ORIN: “Lílé - Òrínlááse ni rí ao elèrò l’ufe o’ Ègbè – Ao elèrò o

Lílé – Àjàká lao elèrò l’úfé ó

Ègbè – Ao elèrò o

Lílé - Òràn lao elèrò l’úfè ò

Ègbè – Ao elèrò o

Lílé - Olúorókè lao elèrò l’úfè ó

Ègbè – Ao elèrò o