Isele Kayeefi
From Wikipedia
Isele Kayeefi
C.O. Elegbeleye
C.O. Elégbéléye, (2005), “Àgbéyèwò ìtàn Ìsèlè Kàyééfì lórí Rédíò’, Àpilèko fún Oyè Eémeè, DALL, OAU, Ifè, Nigeria.
[edit] ÀSAMÒ
Nínú isé yìí, a gbìyànjú àti se àgbéyèwò ewà, ìhun àti èdè nínú ìtàn ìsèlè kàyéèfì Yorùbá lórí rédíò. A sapá láti wo àwon ìtàn ìsèlè kàyéèfi tí wón ń so nínú àwon ètò bí i “Gba-n-kogbì”, ‘Ó-séléńké-jò” “Òwúyé” àti “Tatíwere”. A sì tiraka láti wo àwon ìsèlè ìyànu tí ó súyo nínú àwon ìtàn yìí lórí rédíò.
Onà pàtàkì tí a gbà se ìwádìí ni síse àbèwò sí ilé-isé méérèrìn tí a yàn láàyò fún isé yìí, pèlú èròngbà láti gba àwon èròjà tí a nílò. A gba ìtàn ìsèlè kàyéèfì méjìléláàdóta sílè. Díè lára ìtàn yìí la gbà sílè pèlú téèpù nígbà tí a sì gba àwon mìíràn láti òdò àwon olóòtú ètò náà. Àwon ilé-isé rédíò ti a lo Ilé-isé Rédíò ti Ìpínlè Òsun, lókè Baálè ní Òsogbo, ilé-isé Rédíò Ìpínlè Ondo àkókó lóríta Òbèlé ní Àkúré, Ilé isé Rédíò lóríta Basòrun, Ìbàdàn àti Rédíò amìjìnjìn lókè Màpó, Ìbàdàn. A tún se ìfòrò-wáni-lénu-wò pèlú àwon Gííwá Ilé isé Rédíò wònyìí ní òkòòkan àti àwon olóòtú ètò ilé isé mérin òkè yìí lórí irúfé èdá ìtàn, orú ìtàn tó jé, ètò àgbékalè ìtàn láti mò bóyá ìtàn ìsèlè-ojú ayé ni. A tún sé ìwádìí lórí ipa àwon onígbòwò ètò wònyìí àti èrè won lórí ètò yìí. A se àbèwò sí ilé-ìkàwé fún ìwádìí lórí àwon ohun tí ó je mó àkosílè lórí isé yìí. A se àdàko àbò oko ìwádìí. A sì fi tíórì ìlànà ìmútànso se gbogbo àtúpalè tí a gbà sílè.
Ìsé ìwádìí yìí se àseyorí nípa síse àfikún ìmò lórí ètò ìtàn ìsèlè kàyéèfì Yorùbá lórí radio. A rí pé ó jé ètò tó gbájú gbajà, tó sì se àkópò ìmò àwon ènìyàn nípa ohun tó ń selè tó je mó àsà àti ìse wa. Won ń gbé ètò náà kalè nípa síse àmúlò onà èdè bíi ìpanilérìn-ín àti orísìírísìí ìyapa. Asì rí pé ìkóniláyàsókè jé ogbón ìsòtàn pàtàkì. Ìtàn wònyìí kojá òye èdá lórí ìsèlè ojoojúmó, ó jo ni lójú púpò gidigidi, àwon ìtàn wònyìí kún fún ìsèlè ìyànu, tó mèrù bani, àwon ìsèlè tí a lérò pé kò lè selè ní àwùjo tó wá ń selè tó kóni láyà je, tó sì yàtò sí ìwà omolúwàbí. Àwon ìwà bíi ká fi ènìyàn se òògùn owó, lílo agbára òkùnkùn tó le. Ìlò èdè àwon olóòtú, ètò ìtàn ìsèlè kàyéèfì jé èyí ló lówúra, tó kún fún àkànlò èdè, èdà òrò, àti àmúlò òwe tó bójú mu. Àwon se àmúlò àwítúnwí, àpèjúwe, àfiwé, orin kò gbéyìn rárá. Pàtàkì èyí ni láti fi ewà ètò náà hàn. Nígbà mìíràn, asòtàn lè pín odidi ìtàn ìsèlè kàyéèfì kan sí ònà méta tàbí mérin ìdí èyí ni láti fi ààyè gba ìpolówó-ojà àti láti jé kí àwon àwon olùgbó ètò kó ipa pàtàkì nípa síso èrò okàn won. Asòtàn á wá so ìtàn náà ní sísé-n-tèlé fún òsè méta tàbí mérin ní ìbámu pèlú bí àsòtàn se pín-in.
Ní ìparí, a fi ìdí rè múlè pé ìtàn ìsèlè kàyéèfì ara lítírésò alohùn Yorúbá ni. Ní pàtàkì òpò àbùdá tó je mó èyà lítírésò alohùn bí i òwe, ìfòròdárà, àwàdà, àsorégèé ló wópò nínú ìtàn wònyí. Ìrètí wa ni pé isé ìwádìí yìí yóò jé àtègùn tí àwon isé mìíràn lórí rédíò yóò máa gùn lé lójó iwáju.
Alábòójútó: Prof. Bádé Àjùwòn
Ojú-Ìw é: 186
C.O. Elégbéléye, (2005), “Àgbéyèwò ìtàn Ìsèlè Kàyééfì lórí Rédíò’, Àpilèko fún Oyè Eémeè, DALL, OAU, Ifè, Nigeria.
ÀSAMÒ
Nínú isé yìí, a gbìyànjú àti se àgbéyèwò ewà, ìhun àti èdè nínú ìtàn ìsèlè kàyéèfì Yorùbá lórí rédíò. A sapá láti wo àwon ìtàn ìsèlè kàyéèfi tí wón ń so nínú àwon ètò bí i “Gba-n-kogbì”, ‘Ó-séléńké-jò” “Òwúyé” àti “Tatíwere”. A sì tiraka láti wo àwon ìsèlè ìyànu tí ó súyo nínú àwon ìtàn yìí lórí rédíò.
Onà pàtàkì tí a gbà se ìwádìí ni síse àbèwò sí ilé-isé méérèrìn tí a yàn láàyò fún isé yìí, pèlú èròngbà láti gba àwon èròjà tí a nílò. A gba ìtàn ìsèlè kàyéèfì méjìléláàdóta sílè. Díè lára ìtàn yìí la gbà sílè pèlú téèpù nígbà tí a sì gba àwon mìíràn láti òdò àwon olóòtú ètò náà. Àwon ilé-isé rédíò ti a lo Ilé-isé Rédíò ti Ìpínlè Òsun, lókè Baálè ní Òsogbo, ilé-isé Rédíò Ìpínlè Ondo àkókó lóríta Òbèlé ní Àkúré, Ilé isé Rédíò lóríta Basòrun, Ìbàdàn àti Rédíò amìjìnjìn lókè Màpó, Ìbàdàn. A tún se ìfòrò-wáni-lénu-wò pèlú àwon Gííwá Ilé isé Rédíò wònyìí ní òkòòkan àti àwon olóòtú ètò ilé isé mérin òkè yìí lórí irúfé èdá ìtàn, orú ìtàn tó jé, ètò àgbékalè ìtàn láti mò bóyá ìtàn ìsèlè-ojú ayé ni. A tún sé ìwádìí lórí ipa àwon onígbòwò ètò wònyìí àti èrè won lórí ètò yìí. A se àbèwò sí ilé-ìkàwé fún ìwádìí lórí àwon ohun tí ó je mó àkosílè lórí isé yìí. A se àdàko àbò oko ìwádìí. A sì fi tíórì ìlànà ìmútànso se gbogbo àtúpalè tí a gbà sílè.
Ìsé ìwádìí yìí se àseyorí nípa síse àfikún ìmò lórí ètò ìtàn ìsèlè kàyéèfì Yorùbá lórí radio. A rí pé ó jé ètò tó gbájú gbajà, tó sì se àkópò ìmò àwon ènìyàn nípa ohun tó ń selè tó je mó àsà àti ìse wa. Won ń gbé ètò náà kalè nípa síse àmúlò onà èdè bíi ìpanilérìn-ín àti orísìírísìí ìyapa. Asì rí pé ìkóniláyàsókè jé ogbón ìsòtàn pàtàkì. Ìtàn wònyìí kojá òye èdá lórí ìsèlè ojoojúmó, ó jo ni lójú púpò gidigidi, àwon ìtàn wònyìí kún fún ìsèlè ìyànu, tó mèrù bani, àwon ìsèlè tí a lérò pé kò lè selè ní àwùjo tó wá ń selè tó kóni láyà je, tó sì yàtò sí ìwà omolúwàbí. Àwon ìwà bíi ká fi ènìyàn se òògùn owó, lílo agbára òkùnkùn tó le. Ìlò èdè àwon olóòtú, ètò ìtàn ìsèlè kàyéèfì jé èyí ló lówúra, tó kún fún àkànlò èdè, èdà òrò, àti àmúlò òwe tó bójú mu. Àwon se àmúlò àwítúnwí, àpèjúwe, àfiwé, orin kò gbéyìn rárá. Pàtàkì èyí ni láti fi ewà ètò náà hàn. Nígbà mìíràn, asòtàn lè pín odidi ìtàn ìsèlè kàyéèfì kan sí ònà méta tàbí mérin ìdí èyí ni láti fi ààyè gba ìpolówó-ojà àti láti jé kí àwon àwon olùgbó ètò kó ipa pàtàkì nípa síso èrò okàn won. Asòtàn á wá so ìtàn náà ní sísé-n-tèlé fún òsè méta tàbí mérin ní ìbámu pèlú bí àsòtàn se pín-in.
Ní ìparí, a fi ìdí rè múlè pé ìtàn ìsèlè kàyéèfì ara lítírésò alohùn Yorúbá ni. Ní pàtàkì òpò àbùdá tó je mó èyà lítírésò alohùn bí i òwe, ìfòròdárà, àwàdà, àsorégèé ló wópò nínú ìtàn wònyí. Ìrètí wa ni pé isé ìwádìí yìí yóò jé àtègùn tí àwon isé mìíràn lórí rédíò yóò máa gùn lé lójó iwáju.
Alábòójútó: Prof. Bádé Àjùwòn
Ojú-Ìw é: 186