Edee Yoruba I
From Wikipedia
Adeleke, D. Adeyemi
ADELEKE D. ADEYEMI
ÈDÈE YORÙBÁ
Èdèe Yorùbá jé èdè kan tó gbajú-gbajà ní Orílè-èdè nàìjírìa àti kárí gbogbo àgbáyé lápapò, èdèe Yorùbá jé èdè kan tí kò sé f’owó ró séyìn nínú gbogbo èdè àgbáyé a gbó wí pé Yoàrìbá ní wón ń pe àwon Yorùbá télè, sùgbón nígbà tí ó di odún (1843) ni Bishop Àjàyí Crowther yí Orúko yìí padà làti Yàrìbá sí Yorùbá, a gbó wí pé níbèrè pèpè, nígbà tí wón fé so àwon èyà Yorùbá yìí pò, wón bèrè pèlú “ekú”, bí àpeere, Ekú àárò, Ekú òsán, Ekú alé, Ekú Ìyálèta, Ekú isé, Ekú àbò, Ekú àgbà àti béèbéè lo.
A gbó wí pé àwon eni àkókó tó dìde láti so èdè Yorùbá di kíko sílè ni – Hannnh Kilham, John Rabar, Bishob Àjàyí Crowther àti Bowdich, Ìtàn ní Bowdich ni eni àkókó tí ó kókó gbìyànjú láti ko èdè Yorùbá sílè, bíi Òkan, Èjì, Èta, arábìnrín Hannah Kilham náà ko ìwé kan ní odún (1828) ní eléyìí tí ó pè ní “The Specimen of African Language Spoken in the Coloning of Sierra leone” nínú isé yen ni ó pè ní “Akù” Arábìnrin yìí náà ni ó dábàá ìlànà A, B, D. A tún gbó wí pé arákùnrin kan tí orúko rè ń jé Edwin Morris tún gbìyànjú ní Odún (1841) isé tirè tó se ni “Outline of a vocabulary of a view of the principle Language of Western and Central Africa Compilled for the use of the Niger expedition, ò hun náà se àlàyé lékùn réré sínú isé yen. Enì kerìn-in tí a tún lè so wí pé ó tún gbìyànjú ni, àwon ìjo CMS, ìdí tí wón se dá sí èdè Yorùbá ni wí pé, àwo Òyìnbó tí ó wà nígbà yen, wón se àkíyèsí pé à ì ní àkotó tó ń fa isé àwon séyìn. A gbó wí pé wón se ìpàdé ní London ní odúnr-un(1848) o hun ti ipade náà dá lé lórí ni wí pé, wón fé wá bí ilè Áfíríkà se lè ko èdè sílè, Henry Venn ló sa agbáterù ìpàdé náà, ara àwon òjògbón Linguistic tí wón jo jókòó nígbà náà lóhùn-ún ni arákùnrin J.P. Sohon, Alufa S. lee Òjògbón nínú èdè Arabic àti Heberu, Ó wá láti University of Cambridge. Elòmíràn tí ó tún dá sí ètò náà ni Henry Townsend, a gbó wí pé olùtèwé ni, ò hun sì ni Olóòtú ìwé ìròyìn. Èdè Yorùbá kì í se èdè tí a lè fowó ró séyìn rárá nítorí pé ó ti di gbajú-gbajà èdè ní orílè èdè Nàìjíríà, a ń so èdè Yorùbá ní àwon ìpínlè bíi Lagos, Ògùn, Òyó, Òsun, Òndó, Èkìtì, Kwara ati Kogí, a tún lè so wí pé àwon tó ń so èdè Yorùbá kò dín ní Ogbòn milioonu yàtò sí orílè-èdè Nàìjíríà, a tún ń so èdè Yorùbá ní àwon Orílè-èdè bíi-Benue, Togo, Ghana, Sudan ati Sierra Leone. Ní Orílè-èdè àgbáyé lápapò, a ń so èdè Yorùbá ní Brazil, Kuba, Trinidad and Tobago, u.K. àti America. Ní orílè-èdè America, Ilé èkó gíga mókàndínlógbòn ni wón ti ń kó èdè Yorùbá. Èdè yíí jé èdè tí ó gbajú-gbajà ní orílè-èdè America, bí ó tilè jé wí pé a ń pò mó-ón erè lódò tiwa.