Bamiji Ojo

From Wikipedia

Bamiji Ojo

A.O. Adeoye (2000), ‘Ìtàn Ìgbésí Ayé Bámijí Òjó’, láti inú Àtúpelè Ìwé Oba Adìkúta tí Bámijí Òjó ko.’, Àpilèko fún Òyè Bíeè, DALL, OAU, Ifè Nigeria.

Itàn Ìgbésí Ayé Bámijí Òjó

A bí Bámijì Òjó ní egúnjó osù kewàá odún 1939 ní ìlú ìlóràá, ní ìjoba ìbílè Afijió ní ìpínlè Òjó. Orúko àwon òbí rè ni Jacob Òjó àti Abímbólá Àjoké Òjó. Isé àgbè ni àwon òbí rè ń se.

Ojú ti ń là díè nígbà náà, eni tí ó bá mú omo lo sí ilé-ìwé ní ìgbà náà, bí ìgbà tí ó fi omo sòfà tí ó mú omo lo fún òyìnbó ni. Sùgbón àwon òbí rè pa ìmò pò wón fi sí ilé-ìwé alákòóbèrè ti ìjo onítèbomi ti First Baptist Day School ìlú Ìloràá ni odún 1946. O se àseyerí nínú èkó oníwèé méfà, tí ó kà jáde ni ilé-ìwé alákòóbèrè. Nígbà náà wón ti ń dá ilé èkó gíga Módà (Modern School) sílè. Bámijí Òjó se ìdánwò bó sí ilé-ìwé Local Authority Modern School ní ìlú Fìdítì, ó wà ní ibè fún odún méta (1956-1959).

Léyìn èyí nínú odún 1960, Bámijí Òjó se isé díè láti fi kówó jo. Nítorí pé kò sí owó lówó àwon òbí rè láti tó o kojá ìwé méjo. Léyìn tí ó ti sisé tí ó sì kówó jo fún odún kan pèlú ìwé èrí “Modern School”, ó tún tíraka láti tèsíwájú lénu ìwé rè. Ó lo sí ilé-ìwé ti àwon olùkóni ti “Local Authority Teacher Training College” ní ìlú Òyó láti inú odún 1961 di odún 1962.

Ìgbà tí ó parí èkó rè ni ó bèrè isé tísà, bí ó tilè jé pé kì í se isé tí ó wù ú lókàn gan-an láti ilè pèpè ni isé tísà. Ó se isé tísà káàkiri àwon ìpínlè bí i Sakí, Edé, Ahá. Sùgbón isé ìròyìn ni ó múmú ní okàn rè.

Bámijí Òjó wà lára àwon méjìlá àkókó tí wón gbà ní odún 1969 láti kó Yorùbá ní Yunifásitì Èkó. Nígbà náà ojú òle ni wón fi máa ń wo eni tí ó bá lo kó Yorùbá ní Yunifásitì.

Léyìn tí ó parí èkó rè ni wón gba Bámijí Òjó sí ilé isé ìròyìn ní odún 1970, Àlhàájì Lateef Jákàńdè ni ó gbà á sí isé ìròyìn ní ilé-isé “Tribune”ní ìlú Èkó, gégé bí igbá kejì olóòtú Ìròyìn Yorùbá. Sùgbón nítorí pé ó tin í ìyàwó nílé nígbà náà wón gbé e padà sí Ìbàdàn. Ilé-isé won wà ní Adéòyó. Ní àsìkò yìí kan náà ni Bámijí Òjó ronú pé isé ìròyìn ti orí Rédíò Sáá ní ó wu òun. Ó wá ń bá won sisé aáyan ògbufò ni ilé-isé “Radio Nigeria”. Èyí ni ó ń se tí ó fi ń sisé nílé isé “Tribune” àti nílé isé “Radio Nigeria”.

Ní odún 1971 ni wón gba Bámijí Òjó gégé bí onísé Ìròyìn ní ilé isé “Radio Nigeria”. Àwon tí wón jìjo sisé ìròyìn nígbà náà ni Alàgbà Oláòlú Olúmìídé tí ó jé ògá rè, Olóògbé Àlhàájì Sàká Síkágbó àti Olóògbé Akíntúndé Ògúnsínà àti bàbá Omídèyí.

Nítorí ìtara okàn tí Bámijí Òjó ní láti sisé nílé isé Telifísàn ó kúrò ní “Radio Nigeria”, ó lo sí “Western Nigerian Broadcastint Service” àti “Western Nigerian Televeision Station” WNBS/WNTV tó wà ní Agodi Ìbàdàn, nínú osù kokànlá odún 1973. Ni ibè ni okà rè ti balè tí àyè sì ti gbà á láti lo èbùn rè láti gbé èdè, àsà àti lítírésò Yorùbá láruge. Ìràwò rè si bèrè sí í tàn gidigidi lénu isé ìròyìn. Nígbà ti Bámijí Òjó wà ní “Radio Nigeria” kí ó tó lo sí “Western Nigerian Television Station (WNTV)” ni wón ti kókó ran àwon onísé ibè lo sí ilé èkó láti lo kó èkó nípa bí wón se ń sisé nílé isé Rédíò. Ilé isé Rédíò ní Ìkòyí ni won ti gba idánilékòó yìí. Ìdí nip é tí ènìyàn bá máa sòrò nílé isé “Radio Nigeria”nígbà náà ó gbódò kó èkó. Lára àwon ètò tó máa ń se lórí èro Telifísàn ni “Káàárò-oò-jíire” àti “Tiwa-n-tiwa” túbòsún Oládàpò, Láoyè Bégúnjobí àti àwon mìíràn ni wón jo wà níbi isé nígbà náà. Gbogbo akitiyan yìí mú kí ìrírí Bámijí gbòòrò si nípa isé ìròyìn àti ìsèlè àwùjo pèlú àwon ènìyàn inú rè.

Ní odún 1976 ni Bámijí Òjó lo fún ìdáni lékòó ní Òkè Òkun, ní orílè èdè kenyà níbi tí ó ti gba ìwé èrí “Certificate Course In Mass Communication” (Ìlànà Ìgbétèkalè lórí aféfé).

Nígbà tí ó di osù kewàá odún 1976, ni wón dá àwon ìpínlè méta sílè, Òyó, Òndó àti Ògùn, Bámijí jé òkan lára àwon tí ó kúrò ni ilé isé “Western Nigerian Broadcasting Services” àti “Western Nigerian Television Station (WNBS/WNTV) tí ó lo dá Rédíò Òyó sílè. Engineer Olúwolé Dáre ni ó kó won lo nígbà náà, Kúnlé Adélékè, Adébáyò ni wón jìjo dá ilé isé Rédíò sí lè ni October 1976, wón kó ilé isé won lo sí Oríta Basòrun Ìbàdàn.

Nínú odún 1981 ni Bámijì Òjó tún pa isé tì, tí ó tún lo fún ètò ìdánilékòó lórí bí a se ń se isé Rédíò ní ilé isé Rédíò tí ó jé gbajúgbajà ní àgbáyé tí won ń pè ní “British Broadcasting Co-operation (BBC) London fún Certificate Course.

Ní odún 1983 ni ó lo sí orílè èdè Germany fún ìdánilékòó Olósù méta ní ilé isé Rédíò tí à ń pè ni “Voice of Germany”. Níbè ló ti kó èkó nípa isé Rédíò àti Móhùnmáwòrán. Ìgbà tí Bámijì Òjó dé ni ó jókòó ti isé tí ó yìn láàyò. Èyí ni ó ń se títí tí wón tún fi pín Òyó sí méjì tí àwon Òsun lo, èyí mú kí ànfààní wà láti tè síwájú. Orísìírísìí ìgbéga ni ó wáyé nígbà náà sùgbón ìgbéga tí ó gbèyìn nínú isé oníròyìn ni “Director of Programmes’ tí wón fún Bámijí Òjó nínú osù kesàn-án, odún 1991, Ó sì wà lénu isé náà gégé bí olùdarí àwon èka tí ó ń gbóhùn sáféfé títí di odún 1994. Ojó kokànlélógbòn osù kejìlá odún 1994 ni ó fèyìn tì.

Ní odún tí ó tèlé, nínú osù kìíní odún 1995 ni Bámijì Òjó dá ilé isé tirè náà sílè. Èyí tí ó pa orúko rè ní ‘Bámijí Òjó Communicatio Center’.

Bámijì Òjó tin í iyàwó béè ni Olórun sì ti fi omo márùn-ún dá a lólá.

Orísìírísìí èbùn móríyá àti ìkansáárásí ni Bámijí Òjó gbà nígbà tí ó wà lénu isé ijoba. Fún orí pí pé àti ìmò ìjìnlè rè tí ó fi hàn ní ilè Germany. Ó gba onírúurú èbùn fún àseyorí àti àseyege ní òpin èkó náà. Pèlú ìrírí àti èkó tó kó ní ‘London’ àti ‘Germany’ó di omo egbé tí a mò sí ‘Overseas Broadcasters’ Association’.

Ní odún 1990 ni ògágun Abudul Kareem Àdìsá fún Bámijí Òjó ní èbùn ìkansáárá sí, èyí ni ‘Òyó State Merit Award for the best producer or the year’. Fún ìmo rírì ètò tí ó ń se ní orí ‘Television Broadcasting Co-operation Òyó State (BCOS)’ Só Dáa Béè tí àwon ènìyàn ń jé ànfààní rè, Aláyélúwà Oba Emmanuel Adégbóyèga Adéyemo Òpérìndé 1. ni ó fi oyè Májèóbà jé ti ilú Ìbàdàn dá a lólá, nínú osù kokànlá odún 1994. 1.5 Bámijì Òjó Gégé Bi Ònkòwé Ìwé Ìtàn Àròso Yorùbá

Ìwé kíko je ohun ti Bámijì Òjó nífèé sí. Oba Adìkúta jé òken lára ìwé méjì sí méta tí ó ti ko jáde.

Ìwé àkókó tí Bámijì Òjó ko jáde ni Ménumó. Ìwé yìí jáde ni odún 1989.

Léyìn èyí ni Bámijì Òjó ko ìwé rè kejì. Oba Adìkúta tí ó jáde nínú osù keta odún 1995.

Nígbà tí Bámijì Òjó wà ní ilé isé “Radio Nigeria” ni ó ti kókó ko ìwé kan tí ó pè ní Àsà Àti Òrìsà Ilè Yorùbá. Ìwé yìí wà lódò àwon atèwétà tí ó gbàgbé sí won lódò tí kò sì jáde di òní olónìí.

Bámijì Òjó gégé bí enìkan tí ó ní ìtara okàn. ó tún ní àwon ìwé méjì tí ó wà lódò rè tí yóò jáde ní àìpé. Àkókó ni Sódaa Béè. Ìwé yìí jé àbájáde ètò kan tí ó se pàtàkì lórí Rédíò.

Òmíràn ni ètò Èyí Àrà. Bámijí Òjó ni ó dá ètò náà sílè¸ní ojó kìíní osù kerin odún 1984. Ní ilè Yorùbá pàápàá jù lo “South West”, òun ni ó bèrè rè, kò sí ilé isé Rédíò tí ó síwájú rè bèrè ètò yìí “Phone In” Èyí Àrà.