Oba Adikuta
From Wikipedia
O.A. Adeoye
Oba Adikuta
O.A. Adeoye (200), ‘Oba Adikúta ní Sókí’, láti inú Àtúpalè Ìwé Oba Adìkúta tí Bámijí Òjó ko.’, Àpilèko fún Oyè Bíeè, DALL OAU, Ifè, Ojú-ìwé 13-17
Ìsonísókí Ìwé Ìtàn Àròso Oba Adìkúta
Ìlú ìyona jé ìlú tí ó kún fún orísìírísìí ìwà burúkú, èyí tí kò jé kí wón ní ìlosíwájú. Ní àkókò tí oba ìlú ìyonu kábíyèsí Oba Morólágbé Tèmiladé Adìkúta kejì wà jà ni ìtàn náà bèrè, ònkòwé sàlàyé gbogbo ònà tí àwon arà ìlú náà ń gbà se òfò oba won. Léyìn àkókò òfò yìí ni àwon ará ìlú bèrè sí ní í gbìmòràn àti yan oba mìíràn sórí ìté. Èyí ni ó fa ìpàdé àkókó tí ìdílé Àdìkúta pe, gbogbo omo oyè tí ó ní fèé sí ìté náà ni ó fi orúko sí lè. Òmo Oba gbólágadé Adéoyè gégé bí akòwé fún ìjókòó àwon omo Oba ni wón yàn láti kòwé sí àwon omo oyè tí ó wà ní ìdálè, sùgbón nínú gbogbo àwon omo oyè tí ó ye kí Gbólágadé ko ìwé sí, omo Oba Morádéyò Adékòyà ni o wù ú kí ó joba. Ìdí nìyí tí ó fi fi gbogbo ara wà léyìn rè.
Ibi tí wàhálà ti kókó bèrè nípa òrò oyè ìlú ìyonu ni pé dípò ènìyàn márùn-ún tí ó ye kí Gbólágadé ko ìwé sí àwon méta péré ni ó ko ìwé sí. Nnkan òtòòtò ni ó sì ko sí àwon métèèta. Sùgbón nínú ìwé ti omo Oba Adékòyà ni ó fi so fún un pé Oba ti wàjà àti pé òun ni ìdílé Adìkúta fà sílè gégé bí omo Oyè, àwon ìlú sì ń retí rè.
Kò pé púpo tí Adékòyà rí ìwé náà gbà. Ìsesí Adékòyà nígbà tí ó ń ka ìwé náà fi hàn pé kì í se ìfe inú rè láti joyè náà sùgbón pèlú gbogbo ifowósowópò àti ìmòràn láti òdò ìyàwó àti òré rè. Adékòyà gbà láti jé ì pè mòlébí. Láti ìgbà náà ni Adékòyà àti ìyàwó rè ti bèrè sí ní í se ìpalèmó. Nítorí omolúàbí tí Adékòyà jé, orísìírísìí ebùn àti ayeye ìdágbére ni wón se fún un níbi isé rè. Orísìírísìí ìwé àdéhùn olójó gbooro ni Adékòyà fowó sí kí àwon òyìnbó lè se àtiléyìn fún un ní pa àwon ohun amáyéderùn fún ìlú rè. kí Adékòyà tó kó erù sónà ó ti ko ìwé síwájú pé òun ti gbà láti je oyè náà, léyìn èyí ni Adékòyà fi ìlú kánádà sílè ní ìrètí pé àwon ará ìlú àti mòlébí ń dúró de òun láti wá joba ìlú Ìyonu.
Ní ìparí ìpàdé àkókó tí àwon mòlébí se, ènìyàn méjì ni ó fi orúko sílè, léyìn tí àwon márùn-ún mìíràn forúko sílè nínú ìpàdé yìí ni omo oba Gbólágadé tó sesè fit ó àwon mòlébí láti pé omo oba Adékòyà ko ìwé ránsé pé òun náà ń bò láti wá figbagbága pèlú àwon elegbé òun. òrò pé àwon omo oyè tó ń dí je ti pòjù ni ó fa kí àwon omo oyè máa tu tó sókè fojú gbà á tí ìpàdé ojó náà fi túká. Ní ojó yìí gan an ni Adékòyà fóònù sí Gbólágadé pé òun yóò dé sí ìlú. Ìgbà tí orúko àwon omo oyè ti dé òdò àwon ìgbìmò afobaje ni wón ti bèrè ìwádìi lórí omo oyè kòòkan. Gbólágadé àti méjì nínú àwon àbúrò Adékòyà ni ó lo pàdé Adékòyà àti àwon mòlébí rè, létí okò òfúúrufú, Ènìyàn méta péré tí ó wá pàdé Adékòyà ni ó jé kàyééfì fún un.
Ìgbà tí Adékòyà ti dé sí ìlú Ìyonu ni ara ti ń fún un nítorí pé gbogbo nnkan tí ó ní ìrètí láti bá kó ni ó bá. Nínú òrò rè pèlú Gbólágadé àti Baba Kékeré ni ó ti rí i pé ìsòro wà fún òun. Ó rí àrídájú pé ìlú kò dúró de òun láti wá joba. Adékòyà fi ìjà peéta pèlú Baba Kékeré. Ní àsìkò yìí ni Gbólágadé ráàyè sá lo. Ìgbà tí òrò ní ìyanjú tán ni Adékòyà rí i pé Gbólágadé ni ó kàn dá isé tirè jé àti pé Gbólágadé náà tin a pápá bora. Adékòyà fò sánlè ó dákú, ìdààmú dé bá ìyàwó rè. Ó bèrè sí ní í so kántan kàntan. Pèlú ìbànújé ni àwon òré Adékòyà fi padà sí Kánádà láìrò télè.
Léyìn osù kesàn-án tí enu àwon omo ìgbìmò kò ni wón pe àwon omo oyè láti fòrò wá won lénu wò. Síwájú àkókò yìí òkan nínú àwon omo oyè náà ti jé Olórun nípè. Omo oyè kòòkan sòrò nípa ara rè, isé tí ó ń se, ipò rè jàdùdà páálí àti jàndùkú ènìyàn ni. Rògbòdìyàn náà pò débi pe owó àwon olópàá kò ká a àyàfi ìgbà ti wón pàsè kónílégbélé. Olóyè Òdòfia tí ó ti rí òye pé àwon ará ìlú kò féràn Olátidóyè ni ó gbà á ní ìmòràn pé kí ó máa há owó kiri fún àwon elégbéjegbé àti àwon ènìyàn pàtàkì mìíràn láàrin ìlú.
Yorùbá bò wón ni. “Òsì ní í jé tan i mò ó rí, owó ní í jé mo ba o tan” Láti ìgbà ti Olátidóyè ti bèrè sí ní í há owó fún gbogbo àwon alátìleyìn Adékòyà ni wón ti ń padà léyìn rè, wón sì bèrè sí ní í se ojú ayé sí i. Ìwé ìròyìn tí ó jáde ni ojó kejì rògbòdìyàn náà ni ó gbé e jáde pé, Olátidóyè di Oba ìlú Ìyonu èyí tí ó bu omi tútù sí okàn àwon ènìyàn. Olátidóyè gégé bí omo egbé ògbóni be àwon egbé rè lówè sí àwon ènìyàn ìlú Ìyonu pé kí won lè féràn òun. Ilè ojó kejì férè má tí ì mó tí àwon ènìyàn fi wá ń kí i. Lára won ni mérin nínú àwon omo oyè, wón sì se ìlérí láti fi-owó-sowóò pèlú rè.
Ó ti hàn gbangba pé kò sí ìrètí fún Adékòyà mó nítorí pé púpò nínú àwon ènìyàn tí ó ń jà fún un ni ó ti di omo èyìn Olátidóyè. Ohun mìíràn ni ti adájó tí Adékòyà gbékèlé tí Olátidóyè ti fowó rà pa àti ilé ìsura ìsèmbáyé tí ó rán àwon jàgùdà láti dáná sun. Adékòyà ko etí ikún sí ìmòràn àwon òbí rè pé kí ó padà sí kánádà, ní àtàrí ilé ìsura ìsèmbáyé tí ó jóná, Adéjó sún ejó náà síwájú. Adékòyà lo sí èwòn nípa sísè sí òfin ilé ejó. Ojó kejì tí Adékòyà wo èwòn Gbólágadé wo ìlú pèlú okò ayókélé. Kí Adékòyà tó ti èwòn dé wón ti bèrè sí sí í se orísìírísìí ìpalèmó fún ayeye ìfinijoyè. Adékòyà rí i pé kò sí ìrètí fún òun mó nípa òrò oyè náà, ó kò láti padà sí Kánádà, sùgbón ó rán ìyàwó àti àwon omo rè padè sí Kánádà. Adékòyà poùnso sùgbón kí ó tó pokùnso ó ko ìwé sílè nínú èyí tí ó ti gbé àwon ará ìlú Ìyonu bú. Ojó keta ti Adékòyà kú ni wón já ewé oyè lé Olátidóyè lórí. Nínú òrò ìdúpé Oba máà ni àwon àgbà ilú tí ó ní òye ti mò pé àwon ti wo gàù ní ìlú Ìyonu.
Nínú òrò ìdúpe Oba Olátidóyè níbi ìrántí odún kan tí ó gun orí ìté, ni ó ti sàlàyé irú onà tí òun gbà dé orí oyè àti ònà tí òun yóò gbà láti se àkóso ètò ìlú náà, èyí tí yóò mú ìnira bá àwon ará ìlú Ìyonú. Àwon ará ìlú mò dájú pé àwon ni àwon pe wàhàlà wón sì ti rì i. Òrò won wá ti di isó inú èkú ó ti di àmúmóra. Ní ìparí ìwé náà òrò Adékòyà wá sí ìmúse. èsan wá ń ké lórí gbogbo omo bíbí ìlú Ìyonu nílé lóko àti ní ìrìn-àjò.