Edee Yoruba I

From Wikipedia

Edee Yoruba

Adeleke, D. Adeyemi

ADELEKE D. ADEYEMI

ÈDÈE YORÙBÁ

Èdèe Yorùbá jé èdè kan tó gbajú-gbajà ní Orílè-èdè nàìjírìa àti kárí gbogbo àgbáyé lápapò, èdèe Yorùbá jé èdè kan tí kò sé f’owó ró séyìn nínú gbogbo èdè àgbáyé a gbó wí pé Yoàrìbá ní wón ń pe àwon Yorùbá télè, sùgbón nígbà tí ó di odún (1843) ni Bishop Àjàyí Crowther yí Orúko yìí padà làti Yàrìbá sí Yorùbá, a gbó wí pé níbèrè pèpè, nígbà tí wón fé so àwon èyà Yorùbá yìí pò, wón bèrè pèlú “ekú”, bí àpeere, Ekú àárò, Ekú òsán, Ekú alé, Ekú Ìyálèta, Ekú isé, Ekú àbò, Ekú àgbà àti béèbéè lo.

A gbó wí pé àwon eni àkókó tó dìde láti so èdè Yorùbá di kíko sílè ni – Hannnh Kilham, John Rabar, Bishob Àjàyí Crowther àti Bowdich, Ìtàn ní Bowdich ni eni àkókó tí ó kókó gbìyànjú láti ko èdè Yorùbá sílè, bíi Òkan, Èjì, Èta, arábìnrín Hannah Kilham náà ko ìwé kan ní odún (1828) ní eléyìí tí ó pè ní “The Specimen of African Language Spoken in the Coloning of Sierra leone” nínú isé yen ni ó pè ní “Akù” Arábìnrin yìí náà ni ó dábàá ìlànà A, B, D. A tún gbó wí pé arákùnrin kan tí orúko rè ń jé Edwin Morris tún gbìyànjú ní Odún (1841) isé tirè tó se ni “Outline of a vocabulary of a view of the principle Language of Western and Central Africa Compilled for the use of the Niger expedition, ò hun náà se àlàyé lékùn réré sínú isé yen. Enì kerìn-in tí a tún lè so wí pé ó tún gbìyànjú ni, àwon ìjo CMS, ìdí tí wón se dá sí èdè Yorùbá ni wí pé, àwo Òyìnbó tí ó wà nígbà yen, wón se àkíyèsí pé à ì ní àkotó tó ń fa isé àwon séyìn. A gbó wí pé wón se ìpàdé ní London ní odúnr-un(1848) o hun ti ipade náà dá lé lórí ni wí pé, wón fé wá bí ilè Áfíríkà se lè ko èdè sílè, Henry Venn ló sa agbáterù ìpàdé náà, ara àwon òjògbón Linguistic tí wón jo jókòó nígbà náà lóhùn-ún ni arákùnrin J.P. Sohon, Alufa S. lee Òjògbón nínú èdè Arabic àti Heberu, Ó wá láti University of Cambridge. Elòmíràn tí ó tún dá sí ètò náà ni Henry Townsend, a gbó wí pé olùtèwé ni, ò hun sì ni Olóòtú ìwé ìròyìn. Èdè Yorùbá kì í se èdè tí a lè fowó ró séyìn rárá nítorí pé ó ti di gbajú-gbajà èdè ní orílè èdè Nàìjíríà, a ń so èdè Yorùbá ní àwon ìpínlè bíi Lagos, Ògùn, Òyó, Òsun, Òndó, Èkìtì, Kwara ati Kogí, a tún lè so wí pé àwon tó ń so èdè Yorùbá kò dín ní Ogbòn milioonu yàtò sí orílè-èdè Nàìjíríà, a tún ń so èdè Yorùbá ní àwon Orílè-èdè bíi-Benue, Togo, Ghana, Sudan ati Sierra Leone. Ní Orílè-èdè àgbáyé lápapò, a ń so èdè Yorùbá ní Brazil, Kuba, Trinidad and Tobago, u.K. àti America. Ní orílè-èdè America, Ilé èkó gíga mókàndínlógbòn ni wón ti ń kó èdè Yorùbá. Èdè yíí jé èdè tí ó gbajú-gbajà ní orílè-èdè America, bí ó tilè jé wí pé a ń pò mó-ón erè lódò tiwa.