Awon Itan Aye Atijo
From Wikipedia
Awon Itan Aye Atijo
Thomas Peter Taiwo
THOMAS PETER TAIWO
ÀWON ÌTÀN AYÉ-ÀTIJÓ
Orísirísi ni àwon ògbóntarìgì àwon òpìtàn tabi ònkòtàn tí ó wà tí ó sì ti wà séyìn rí. Àwon òpìtàn wònyìí se isé tó pò jojo lórí ohun tí a lé pè ní oríìrun, àsà, ise, ibi tí ati le è ri, ìdí ìtànkálè ati ònà tí èdè Yorùbá ti di àkoólè láyé òde òní. Òkan tó se gbòógì, eléyí tí n ó sì fé menu ba àwon ìtàn rè nípa orírun Yorùbá ni ògbéni tí a mò, sí Badà sákì, omo Òyó-ilè níí sìí se pèlú. Ó sì so orísirísi ìtàn olókanòjòkan nípa àwon èyà Yorùbá. Ní ìbámu pèlú ìtàn arákùnrin yìí àwon Yorùbá jé omo arákùnrin kan tí à ń pè ní Odùduà. Tí a sì mú wa gbàgbó láti inú ìtàn àtenu-dénu pé omo méje ni óbì tí gbogbo àwon méjèèje wònyí sì ní ohun tí olóríjorí won Jogún láti òdò Bàbá won. Àwon omo náà àti ohun tí wón jogún nì wònyí:
1. Olówu - asukúngbade
2. Alákétun - Ójogún adé
3. Ògìso - Ójògún owó
4. onípópó - Ìlèkè
5. Onísábé - Ójogún eran
6. Òràngún - Jogún aya
7. Òrànyàn - Jógún ilè àti ààfin
Pèlú gbogbo atótónu lóró Odùduà yi, ìtàn kò fi yé wa ní pàtó ibi tí ati gbé bí Odùduà. Sùgbón a ríi gbó láti enu àwon ànkòtàn kan rí pé ó ta okùn láti òmu wá si ilé-ayé ni. Ohun pàtó tó bí oníko yìí kò lé wa sùgbón ìtàn fi yé wa pé láyé tipétipé séyìn-séín rí, àwon Yorùbá kan wà ìlú ígíbíìtì tí àwon kan si wà ní ìlú Mékà (Egypt and Mecca). Àwon tí ó wà ní mecca ni à ń pè ní Yorùbá/Yórúbá” tí àwon tí ó kúrò ni ilè Egypt (íjíbíìtì) ni à ń pè ní “Yorùbá” láti inú àwon oníko wònyí nígbàtí ìwásè ni Yorùbá jeyo bí oníko tí ó kó àwon omo odùduà pò. Síwájú síi, àwon Yorùbá wònyí tí a so pé wón wà ní ìjibiiti àti Mecca wá gbéra wón bèrè ìrìnà jò tí n wón sì ń lo, wón dé ibìkan tí ilè téjú tí ó sì pò jojo ni bè èyí ló mú àwon ènìyàn wònyí tí a mò sí àwon Yorùbá tèdó si ibi tí a so pé ilè ti gbé fè yí èyí ló mú Orúko Ilé-Ifè tí ó túnmòsipé ilè tó fè jeyo jáde tí a sì ń fi ń pe Ilé-Ifè¸ní orírun gbogbo Yorùbá. Èrè, àwo èyà Yorùbá jé èyà tí a kò le è so pé ibi bá yìí ni atilèèrí àwón Yorùbá. Àwon èyà Yorùbá jé èyà tí ó tàn kálè púpò jojo. Èyí rí béè nítorípé ní ayé àtijó, òwò ekú, ogun, òtè, ìfipágbàjoba, ìyàn àti béèbéè lo ló mú kí àwon ènìyàn Yorùbá fón káàkiri sí onírúurú ìlú àti oríléèdè ayé gbogbo. Ní ìparí Odùduà fún ra ra rè kò kó àwon omo rè jo sí ojú kan ní gbàtí yóò fi kú, sùgbón ó pín won kiri ká sí onírúurú ilè àti oríléèdè gbogbo ni. Èyí ni kíhún nínú àwon ìtàn èyà Yorùbá tí ó wà ní apá ìwò oòrùn orílé-èdè Nàìjíríà (Western Nigeria).