Oju Odu Mereerindinlogun

From Wikipedia

Oju Odu Mereerindinlogun

Awon Oju Odu Mereerindinlogun

Odu

Odu Ifa

Wande Abimbola

Wande Abímbólá (1977), Àwon Ojú Odù Mérèèrìndínlógun. Ìbàdàn, Nigeria. University Press Plc, 160pp.

Ìwé yìí jé àkójopò ese Ifá tí amú láti inú àwon Ojú Odù (Olójà) Mérèèrìndínlógún. A mú ese Ifá méjo-méjo láti inú Odù kòòkan bèrè láti inú Èjì Ogbè títí ti ó fi kan Òfún (Òràngún) méjì.

Ìyàtò tí ó wà nínú ìwé yìí àti àwon ìwé Ifá àti ewì àdáyébá mìíràn ni pé a se àlàyé ese Ifá kòòkan tí ń be nínú ìwé yìí leseese. A se èyí nítorí pé a ti se àkíyèsí wí pé àwon ese Ifá wònyí kì í yé àwon akékòó (àti olùkó náà dáadáa nígbà tí won bá ń kà wón. Èdè àtayébáyé ni èdè Òrúnmìlà. Nítorí náà kò ya ‘ni lénu wí pé èdè ifá kì í tètè yé ògbèrì. Ìdí nìyí tí a fi se àlàyé sókísókí lórí ese kòòkan. Fún eni ti ó bá ní òye, tí ó sì ní ìfé sí ese Ifá, a lérò pé àlàyé wònyí ó jèé ìlànà pàtàkì nígbà tí ó ba ń ka ìwé yìí finífiní.

Ní ìbèrè ìwé yìí, a se àlàyé nípa ohun tí Ifá jé gégé bí òrìsà àti ewì àdáyébá Yorùbá. A lérò wí pé àlàyé yìí náà ó ran àwon ònkàwé wa lówó láti mo ipò ti Ifá kó nínú ogbón, ìmò àti ìrírí omo Yorùbá.