Obasa
From Wikipedia
Obasa
Adenrele Obasa
Adenrele Adetimkan Obasa
Obasá
Adenrele Adetimkan Obasa jé ògbóntàrìgì akéwì Yorùbá eni tí ó máa ń sáábà lo àwon orísirísi ònà gégé bíi síse àkójopò orísirísi àwon òwe Yorùbá àti àkànlò èdè láti gbé ewì rè jáde. Fún àpeere tí a bá se àyèwò ewì re tí ó pè ní “Ìkà Eke” a ó ri wípé ó lo àwon òwe àti àkànlò èdè Yorùbá gégé bíi,
Olórun kò dá kanyinkayin
Kó lí ńla bí esin
Àtapa ni ì bá ta’ni
Àtapa ni ì bá tà’ nlà
Orísirísi àwon òwe àti àkànlò èdè ni Obasá lò nínú ewì yí eléyìí tí ó mún kí isé re yàtò sí àwon akegbé rè. Lára àwon nnkan wònyí ni
B’ilè ń gbòsìkà
Bí kò gbe olóòtó
B’ó bá pè títí
Oore a máa sú ni í se!
Ònà mìíràn èwè tí Obasá ń gbà gbé àwon ewì rè jáde ni ìfìrópò. Nípa síse èyí ó máa ń fi àwon òrò tirè rópò àwon òrò àtayébáyé ti a mò mo awon òwe náà. Ó máa ń se eléyìí láti fa èmí àwon ewì rè gùn. Fún àpeere
Enlà gb’ókèèrè ní’yì
Asó b’èse Òkín
Nínú ewì tí Obasá pe àkole rè ni “òun” ni mo ti se àfàyo afò tí ó wà ní òkè yìí. “Òkín” nínú afò yìí ni Obasá lò láti fi rópò “Ìdí” eléyìí tí a mò mo òwe náà. Eléyìí ni á rí fàyo gégé bí Obasá se máa n gbìyànjú láti fi àwon òrò tí ó rí wípé ó bá nnkan ti òun ń so rópò ojúlówó òrò tí àwon Yorùbá maa ńlò yálà nínú òwe ni tàbí àkànlò èdè. Tí a bá fi ojú mú wo. “Òkan" tí Obasá fi rópò “Ìdí” nínú ewì yìí a ó ri wípé won kò ní ìtumò tó jo ara won.
Òkan pàtàkì nínú àwon ònà ti Obasá tún náà ń lò ni “Afikun”. Ní òpòlopò ìgbà Obasá maa ń se àfikún àwon òro tirè món àwon òrò tí a mò mo àwon tí ó máa ńlò. Fún àpeere;
Eni ba n’wni ahun.
Ti ba ń w’ówó ahun
Tí bá ń w’ésè ahun
Odidi ahun ní í rán won.
Nínú afò òkè yí, a ó ri dájú sáká wípé ìlà kejì nínú afò náà jé àfikún eléyìí tí Obasá se sí òwe Yorùbá yìí. Ní tòótó àfikún tí Obasá se yìí kò se àkóbá fún ìtumò òwe yìí síbèsíbè èdè ayàwòrán tí ó lò kò se béè ní àgbára mó to eléyìí tí a ti lo “orí” àti “esè” tí ó tumò sí Odidi ahun gégé bí àwon Yorùbá se máa n lo òwe naa.
Tí a bá se àyèwò fínífíní àwon ewì Obasá a ó ri wípé ó máa ń sáábà ko àwon òrò sílè gégé bí ó se máa ń pe wón lénu. Ìdí sì ni èyí tí ó fi maa ń se àfàgùn àwon ìró fáwèlì nínú àwon, ewì rè. Fún àpeere tí a bá wo ewì rè tí o pè ni Ìkà Eke
…Àtapa ni ì bá táni
Àtapa ni ì bá tà’nlà
Àwon sílébú “ì” tí mo fàlà sí ní ìdí ní òkè yìí jé àpeere bí Obasá se máa ń gbìyàn láti ko ewi rè sílè gélé bí ó se maa ń fi ohùn gbé won jade.
Síwájú si, Obasá tún máa ń lo èdè ayàwòrán òpò nínú àwon ewì rè ni ó jé wípé látàní èyi ni ó se máa n so orúko àwon ewì naá. Nínú ewì re tí ó pè ní “Òtí” Obasá lo onà ede ti à ń pè ni ìsohundènìyàn nínú ewì yìí eléyìí tí ó ti so báyìí wípé,
Oti ati’mo l’aso...
Nínú ewì yí Obasá lo otí gégé bí ènìyàn látàní síso wípé otí a máa ti’molaso. Ní lò ótó tí a bá wo Otí ó jé ohun kan tí kò ní owó tí ó lè fi ti ènìyàn, sùgbón Obasá lo òrò yìí látàrí wípé ti ènìyàn bá ti mun otí yó tán kò sí ohun tí irú eni béè kò le se eléyìí mún mi rántí òwe Yorùbá tí ó so wípé Òmùntí gbàgbe ìsé, otí san ìsé kò san. Ìfòròdárà naa jeyo nínú afò tí ó wà ní òkè yí nítorí wípé Obasá n fi “tí” ati “otí” dárà nínú ewì náà tí a bá yéwò fínífíní.
Láfikún, lára àwon ònà míràn tí a tún lè tóka sí tí Obasá ń gbà se àgbékalè àwon ewì rè ni wípé Obasá máa ń se àmúnlò àwon èdè miiràn eléyìí tí ó yàtò sí èdè Yorùbá nínú àwon ewì rè. Eyí sì ni a le pè ní “Èyá òrò” Lára àwon èdè tí ó máa ń yá wo inú ewì re ni èdè òyìnbó, èdè Lárúbáwá ati ede Awúsá pèlú. Fún àpeere nínú ewì rè kan tí ó ti n júbà ògá re. Obasá so báyìí wipe
Ìbà tí mo jú’ un
T’o gá a mi ni
Ògbéni G.A. Williams onínúre
Edito àgbà n’ilè Èkó
Nínú ewì yìí a ó ri wípé Obasá pinnu láti lo èdè Òyìnbó “Editor” nítorí pé àìmoye òrò nínú èdè Yorùbá ni ó wà tí ó le lò sùgbón ó se eléyìí láti fi ara re hàn gégé bí Ògbóntarìgì akéwì èyí tí kò légbé. Lára àwon àyálò èdè rè ni èdè Larubawa níbi tí ó ti so wípé;
Akámuń tàrà kéfà
Fáá làrà búkà
Ó ní
Olórun yíò múnkà sùgbón
Kò ní s’ojú lálákù.
Tí a bá wòó, Obasá lo àwon èdè àyálò wònyí láti fi se ewà sí àwon ewì rè eléyìí si mún ki àwon ènìyàn gbádùn àwon ewì náà.
Níparí, àwon ewì Obasá pín sí ònà méta. Àkókó ni àwon ewì tí ó gbé kalè nipa lilò àwon òwe àti àkànlò ede Yorùbá sán-pán-nán nìkan, gégé bíi “Ìkà Èkè”. Ekeji ni àwon tí ó ko nípa lilo àwon òwe àti àkànlò èdè Yorùbá pelu ogbón isé àtinúdá tirè. Eléyìí tí ó se ìpín keta sì jé àwon isé tí ó kún fún àwon isé àtinúdá tirè nìkan.
Nípa síse àyèwò lórí awon ewi Adenude Obasá wònyí a ó ri dájúdájú wípé ògá pàtàkì ni okùnrin náa jé nínú àwon akéwì Yorùbá.